1

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni náà tí kò gba ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú, tí kò bá àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ rìn, tí kò sì bá àwọn ẹlẹ́gàn kẹ́gbẹ́.

2 Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ní ìfẹ́ sí òfin OLUWA, a sì máa ṣe àṣàrò lórí rẹ̀ tọ̀sán-tòru.

3 Yóo dàbí igi tí a gbìn sí etí odò tí ń so ní àkókò tí ó yẹ, tí ewé rẹ̀ kì í rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá dáwọ́lé níí máa yọrí sí rere.

4 Àwọn eniyan burúkú kò rí bẹ́ẹ̀, ṣugbọn wọ́n dàbí fùlùfúlù tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ.

5 Nítorí náà àwọn eniyan burúkú kò ní rí ìdáláre, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ kò ní le wà ní àwùjọ àwọn olódodo.

6 Nítorí OLUWA ń dáàbò bo àwọn olódodo, ṣugbọn àwọn eniyan burúkú yóo ṣègbé.

2

1 Kí ló dé tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń bínú fùfù tí àwọn eniyan ń gbìmọ̀ asán?

2 Àwọn ọba ayé kó ara wọn jọ, àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀, wọ́n dojú kọ OLUWA ati àyànfẹ́ rẹ̀.

3 Wọn ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á fa ẹ̀wọ̀n tí wọ́n fi dè wá já kí á sì yọ ara wa kúrò lóko ẹrú wọn.”

4 Ẹni tí ó gúnwà lọ́run ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín; OLUWA sì ń fi wọ́n ṣe yẹ̀yẹ́.

5 Lẹ́yìn náà, yóo sọ̀rọ̀ sí wọn ninu ibinu rẹ̀, yóo dẹ́rùbà wọ́n gidigidi ninu ìrúnú rẹ̀,

6 Yóo wí pé, “Mo ti fi ọba mi jẹ, ní Sioni, lórí òkè mímọ́ mi.”

7 N óo kéde ohun tí OLUWA pa láṣẹ ní ti èmi ọba; Ó wí fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi, lónìí ni mo bí ọ.

8 Bèèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fún ọ ní àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ayé yóo sì di tìrẹ.

9 Ìwọ óo fi ọ̀pá irin fọ́ wọn, o óo sì fọ́ wọn túútúú bí ìkòkò amọ̀.”

10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin onídàájọ́ ayé, ẹ gba ìkìlọ̀.

11 Ẹ fi ìbẹ̀rù sin OLUWA, ẹ yọ̀ pẹlu ìwárìrì.

12 Ẹ júbà ọmọ náà, kí ó má baà bínú, kí ó má baà pa yín run lójijì; nítorí a máa yára bínú. Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo àwọn tí ó wá ààbò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀.

3

1 OLUWA, àwọn ọ̀tá mi pọ̀ pupọ! Ọ̀pọ̀ ni ó ń dìde sí mi!

2 Ọpọlọpọ ni àwọn tí ń sọ kiri pé, Ọlọrun kò ní gbà mí sílẹ̀!

3 Ṣugbọn ìwọ OLUWA ni ààbò mi, ògo mi, ati ẹni tí ó fún mi ní ìgboyà.

4 Mo ké pe OLUWA, ó sì dá mi lóhùn láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá.

5 Mo dùbúlẹ̀, mo sùn, mo sì jí, nítorí OLUWA ni ó ń gbé mi ró.

6 Ẹgbẹẹgbẹrun ọ̀tá tó yí mi ká kò le bà mí lẹ́rù.

7 Dìde, OLUWA, gbà mí, Ọlọrun mi! Nítorí ìwọ ni o lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi bolẹ̀, tí o sì ṣẹgun àwọn eniyan burúkú.

8 OLUWA níí gbani, kí ibukun rẹ̀ kí ó wà lórí àwọn eniyan rẹ̀.

4

1 Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́, Ọlọrun mi olùdániláre. Ìwọ ni o yọ mí nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú, ṣàánú mi, kí o sì gbọ́ adura mi.

2 Ẹ̀yin ọmọ eniyan, yóo ti pẹ́ tó, tí ẹ óo máa fi ojú ọlá mi gbolẹ̀, tí ẹ óo máa fẹ́ràn ọ̀rọ̀ asán, tí ẹ óo sì máa wá irọ́ kiri?

3 Ṣugbọn kí ẹ mọ̀ dájú pé OLUWA ti ya olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀, OLUWA yóo gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.

4 Bí ó ti wù kí ẹ bínú tó, ẹ má dẹ́ṣẹ̀; ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀ lórí ibùsùn yín, kí ẹ sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.

5 Ẹ rú ẹbọ òdodo, kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan ni ó ń bèèrè pé “Ta ni yóo ṣe wá ní oore?” OLUWA, tan ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ sí wa lára.

7 Ìwọ ti fi ayọ̀ kún ọkàn mi ju ayọ̀ àwọn tí ó rí ọpọlọpọ ọkà ati ọtí waini nígbà ìkórè.

8 N óo dùbúlẹ̀, n óo sì sùn ní alaafia, nítorí ìwọ OLUWA nìkan ni o mú mi wà láìléwu.

5

1 Fetí sí ọ̀rọ̀ mi, OLUWA; kíyèsí ìmí ẹ̀dùn mi.

2 Fetí sí igbe mi, Ọba mi ati Ọlọrun mi, nítorí ìwọ ni mò ń gbadura sí.

3 OLUWA, o óo gbọ́ ohùn mi ní òwúrọ̀, ní òwúrọ̀ ni n óo máa sọ ẹ̀dùn ọkàn mi fún ọ; èmi óo sì máa ṣọ́nà.

4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọrun tí inú rẹ̀ dùn sí ìwà burúkú; àwọn ẹni ibi kò sì lè bá ọ gbé.

5 Àwọn tí ń fọ́nnu kò lè dúró níwájú rẹ; o kórìíra gbogbo àwọn aṣebi.

6 O máa ń pa àwọn òpùrọ́ run; OLUWA, o kórìíra àwọn apani ati ẹlẹ́tàn.

7 Ṣugbọn nípa ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, èmi óo wọ inú ilé rẹ; n óo fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ wólẹ̀, n óo sì kọjúsí tẹmpili mímọ́ rẹ.

8 OLUWA, tọ́ mi sọ́nà òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi; jẹ́ kí ọ̀nà rẹ hàn kedere níwájú mi.

9 Nítorí kò sí òtítọ́ kan lẹ́nu wọn; ìparun ni ó wà ninu ọkàn wọn. Isà òkú tí ó yanu sílẹ̀ ni ọ̀fun wọn; ẹnu wọn kún fún ìpọ́nni ẹ̀tàn.

10 Dá wọn lẹ́bi, Ọlọrun, kí o sì fìyà jẹ wọ́n; jẹ́ kí ìgbìmọ̀pọ̀ wọn ó gbé wọn ṣubú. Ta wọ́n nù nítorí ọ̀pọ̀ ìrékọjá wọn, nítorí pé wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11 Ṣugbọn jẹ́ kí inú gbogbo àwọn tí ó sá di ọ́ ó dùn, kí wọn ó máa kọrin ayọ̀ títí lae. Dáàbò bò wọ́n, kí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ sì máa yọ̀ ninu rẹ.

12 Nítorí ìwọ OLUWA a máa bukun àwọn olódodo; ò sì máa fi ojurere rẹ tí ó dàbí apata dáàbò bò wọ́n.

6

1 OLUWA, má fi ibinu bá mi wí; má sì fi ìrúnú jẹ mí níyà.

2 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí àárẹ̀ mú ọkàn mi, OLUWA, wò mí sàn nítorí ara ń ni mí dé egungun.

3 Ọkàn mi kò balẹ̀ rárá, yóo ti pẹ́ tó, OLUWA, yóo ti pẹ́ tó?

4 OLUWA, pada wá gbà mí, gbà mí là nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

5 Nítorí kò sí ẹni tí yóo ranti rẹ lẹ́yìn tí ó bá ti kú. Àbí, ta ló lè yìn ọ́ ninu isà òkú?

6 Ìkérora dá mi lágara: ní òròòru ni mò ń fi omijé rẹ ẹní mi; tí mò ń sunkún tí gbogbo ibùsùn mi ń tutù.

7 Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì, agbára káká ni mo fi lè ríran nítorí ìnilára àwọn ọ̀tá.

8 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin oníṣẹ́ ibi, nítorí OLUWA ti gbọ́ ìró ẹkún mi.

9 OLUWA ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, OLUWA ti tẹ́wọ́gba adura mi.

10 Ojú yóo ti gbogbo àwọn ọ̀tá mi; ìdààmú ńlá yóo bá wọn, wọn óo sá pada, ojú yóo sì tì wọ́n lójijì.

7

1 OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo sá di; gbà mí là, kí o sì yọ mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

2 Kí wọn má baà fà mí ya bíi kinniun, kí wọn máa wọ́ mi lọ láìsí ẹni tí ó lè gbà mí sílẹ̀.

3 OLUWA, Ọlọrun mi, bí mo bá ṣe nǹkan yìí, bí iṣẹ́ ibi bá ń bẹ lọ́wọ́ mi,

4 bí mo bá fi ibi san án fún olóore, tabi tí mo bá kó ọ̀tá mi lẹ́rú láìnídìí,

5 jẹ́ kí ọ̀tá ó lé mi bá, kí ó tẹ̀ mí pa, kí ó sì bo òkú mi mọ́ ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

6 OLUWA, fi ibinu dìde! Gbéra, kí o bá àwọn ọ̀tá mi jà ninu ìrúnú wọn; jí gìrì, Ọlọrun mi; ìwọ ni o ti fi ìlànà òdodo lélẹ̀.

7 Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ayé ó rọ̀gbà yí ọ ká, kí o sì máa jọba lé wọn lórí láti òkè wá.

8 OLUWA ló ń ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ayé; dá mi láre, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi ati ìwà pípé mi.

9 Ìwọ Ọlọrun Olódodo, tí o mọ èrò ati ìfẹ́ inú eniyan, fi òpin sí ìwà ibi àwọn eniyan burúkú, kí o sì fi ìdí àwọn olódodo múlẹ̀.

10 Ọlọrun ni aláàbò mi, òun níí gba àwọn ọlọ́kàn mímọ́ là.

11 Onídàájọ́ òdodo ni Ọlọrun, a sì máa bínú sí àwọn aṣebi lojoojumọ.

12 Bí wọn kò bá yipada, Ọlọrun yóo pọ́n idà rẹ̀; ó ti tẹ ọrun rẹ̀, ó sì ti fi ọfà lé e.

13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀, ó sì ti tọ́jú ọfà iná.

14 Wò ó, eniyan burúkú lóyún ibi, ó lóyún ìkà, ó sì bí èké.

15 Ó gbẹ́ kòtò, ó sì jìn sinu kòtò tí ó gbẹ́.

16 Ìkà rẹ̀ pada sórí ara rẹ̀, àní ìwà ipá rẹ̀ sì já lù ú ní àtàrí.

17 N óo fi ọpẹ́ tí ó yẹ fún OLUWA nítorí òdodo rẹ̀, n óo fi orin ìyìn kí OLUWA, Ọ̀gá Ògo.

8

1 OLUWA, Oluwa wa, orúkọ rẹ níyìn pupọ ní gbogbo ayé! Ìwọ ni o gbé ògo rẹ kalẹ̀ lókè ọ̀run.

2 Àwọn ọmọ-ọwọ́ ati àwọn ọmọ-ọmú ń kọrin ògo rẹ, wọ́n ti fi ìdí agbára rẹ múlẹ̀, nítorí àwọn tí ó kórìíra rẹ, kí á lè pa àwọn ọ̀tá ati olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.

3 Nígbà tí mo ṣe akiyesi ojú ọ̀run, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀, tí o sọlọ́jọ̀–

4 Kí ni eniyan jẹ́, tí o fi n náání rẹ̀? Àní, kí ni ọmọ eniyan, tí o fi ń ṣìkẹ́ rẹ̀?

5 O dá a, ipò rẹ̀ rẹlẹ̀ díẹ̀ sí ti ìwọ Ọlọrun, o sì ti fi ògo ati ọlá dé e ní adé.

6 O mú un jọba lórí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, o sì fi gbogbo nǹkan sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀:

7 àwọn aguntan, ati àwọn mààlúù, ati gbogbo ẹranko ninu igbó;

8 àwọn ẹyẹ ojú ọrun, àwọn ẹja inú òkun, ati gbogbo nǹkan tí ó ń lúwẹ̀ẹ́ ninu òkun.

9 OLUWA, Oluwa wa, orúkọ rẹ níyìn pupọ ní gbogbo ayé!

9

1 OLUWA, tọkàntọkàn ni n óo fi dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ; n óo ròyìn gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ.

2 N óo yọ̀, inú mi yóo sì máa dùn nítorí rẹ; n óo kọ orin ìyìn orúkọ rẹ, ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3 Nígbà tí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà, wọ́n ṣubú, wọ́n sì parun níwájú rẹ.

4 Nítorí ìwọ ni o fi ìdí ẹ̀tọ́ mi múlẹ̀, tí o sì dá mi láre; ìwọ ni o jókòó lórí ìtẹ́, o sì ṣe ìdájọ́ òdodo.

5 O bá àwọn orílẹ̀-èdè wí, o pa àwọn eniyan burúkú run, o sì pa orúkọ wọn rẹ́ títí lae.

6 O pa àwọn ọ̀tá run patapata, o sọ ìlú wọn di ahoro, o sì sọ wọ́n di ẹni ìgbàgbé.

7 Ṣugbọn OLUWA gúnwà títí lae, ó ti fi ìdí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀ múlẹ̀.

8 Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé, yóo sì fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè.

9 OLUWA ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, òun ni ibi ìsádi ní ìgbà ìpọ́njú.

10 Àwọn tí ó mọ̀ ọ́ yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ; nítorí ìwọ, OLUWA, kìí kọ àwọn tí ń wá ọ sílẹ̀.

11 Ẹ kọrin ìyìn sí OLUWA, tí ó gúnwà ní Sioni! Ẹ kéde iṣẹ́ rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè!

12 Nítorí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ranti, kò sì gbàgbé igbe ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13 OLUWA, ṣàánú fún mi! Wò ó bí àwọn ọ̀tá mi ṣe ń pọ́n mi lójú. Gbà mí kúrò létí bèbè ikú,

14 kí n lè kọrin ìyìn rẹ, kí n sì lè yọ ayọ̀ ìgbàlà rẹ lẹ́nu ibodè Sioni.

15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jìn sinu kòtò tí wọ́n gbẹ́, wọ́n sì ti kó sinu àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀.

16 OLUWA ti fi ara rẹ̀ hàn, ó ti ṣe ìdájọ́, àwọn eniyan burúkú sì ti kó sinu tàkúté ara wọn.

17 Àwọn eniyan burúkú, àní, gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọrun, ni yóo lọ sinu isà òkú.

18 Nítorí pé OLUWA kò ní fi ìgbà gbogbo gbàgbé àwọn aláìní, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn talaka kò ní já sí òfo títí lae.

19 Dìde, OLUWA, má jẹ́ kí eniyan ó borí, jẹ́ kí á ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè níwájú rẹ.

20 OLUWA, da ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ bò wọ́n, jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé aláìlágbára eniyan ni àwọn.

10

1 Kí ló dé tí o fi jìnnà réré, OLUWA, tí o sì fara pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2 Pẹlu ìgbéraga ni eniyan burúkú fi ń dọdẹ àwọn aláìní; jẹ́ kí ó bọ́ sinu tàkúté tí ó fi àrékérekè dẹ.

3 Eniyan burúkú ń fọ́nnu lórí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀, Ó ń bu ọlá fún wọ̀bìà, ó sì ń kẹ́gàn OLUWA.

4 Eniyan burúkú kò wá Ọlọrun, nítorí ìgbéraga ọkàn rẹ̀, kò tilẹ̀ sí ààyè fún Ọlọrun ninu gbogbo ìrònú rẹ̀.

5 Nígbà gbogbo ni nǹkan ń dára fún un. Ìdájọ́ rẹ, Ọlọrun, ga pupọ, ó ju òye rẹ̀ lọ; ó ń yọ ṣùtì ètè sí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.

6 Ó ń rò lọ́kàn ara rẹ̀ pé, kò sí ohun tí ó lè bi òun ṣubú, ati pé ní gbogbo ọjọ́ ayé òun, òun kò ní ní ìṣòro.

7 Ẹnu rẹ̀ kún fún èpè, ẹ̀tàn ati ìhàlẹ̀; ìjàngbọ̀n ati ọ̀rọ̀ ibi sì wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.

8 Ó ń lúgọ káàkiri létí abúlé, níbi tó fara pamọ́ sí ni ó ti ń pa àwọn aláìṣẹ̀; ó ń fojú ṣọ́ àwọn aláìṣẹ̀ tí yóo pa.

9 Ó fara pamọ́ bíi kinniun tí ó wà ní ibùba; ó fara pamọ́ láti ki aláìní mọ́lẹ̀; ó mú aláìní, ó sì fi àwọ̀n fà á lọ.

10 Ó wó aláìṣẹ̀ mọ́lẹ̀, ó tẹ orí wọn ba, ó sì fi agbára bì wọ́n ṣubú.

11 Ó sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun ti gbàgbé, OLUWA ti gbé ojú kúrò, kò sì ní rí i laelae.”

12 Dìde, OLUWA; Ọlọrun, wá nǹkankan ṣe sí i; má sì gbàgbé àwọn tí a nilára.

13 Kí ló dé tí eniyan burúkú fi ń kẹ́gàn Ọlọrun, tí ó ń sọ lọ́kàn rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò ní bi mí?”

14 Ṣugbọn ìwọ Ọlọrun rí gbogbo nǹkan, nítòótọ́, o kíyèsí ìṣòro ati ìyà, kí o baà lè fi ọwọ́ ara rẹ gbẹ̀san; nítorí ìwọ ni àwọn aláìṣẹ̀ gbẹ́kẹ̀lé, ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìníbaba.

15 Ṣẹ́ eniyan burúkú ati aṣebi lápá, tú àṣírí gbogbo ìwà burúkú rẹ̀, má sì jẹ́ kí ọ̀kan ninu wọn farasin.

16 OLUWA ni ọba lae ati laelae. Àwọn orílẹ̀-èdè yóo pòórá lórí ilẹ̀ rẹ.

17 OLUWA, o óo gbọ́ igbe àwọn tí a nilára; o óo mú wọn lọ́kàn le, o óo sì dẹ etí sílẹ̀ sí igbe wọn

18 kí o lè ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn aláìníbaba ati àwọn ẹni tí à ń pọ́n lójú, kí ọmọ eniyan, erùpẹ̀ lásánlàsàn, má lè dẹ́rù bani mọ́.

11

1 OLUWA ni mo sá di; ẹ ṣe lè wí fún mi pé, “Fò lọ sórí òkè bí ẹyẹ;

2 ẹ wo àwọn eniyan burúkú bí wọ́n ti kẹ́ ọfà; wọ́n fa ọrun; wọ́n sì fi òkùnkùn bojú láti ta olódodo lọ́fà.

3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́, kí ni olódodo lè ṣe?”

4 OLUWA ń bẹ ninu tẹmpili mímọ́ rẹ̀, ìtẹ́ rẹ̀ wà lọ́run; OLUWA ń kíyèsí àwọn ọmọ eniyan, ó sì ń yẹ̀ wọ́n wò.

5 OLUWA ń yẹ àwọn olódodo, ati eniyan burúkú wò, ṣugbọn tọkàntọkàn ni ó kórìíra àwọn tí ó fẹ́ràn ìwà ipá.

6 Yóo rọ̀jò ẹ̀yinná ati imí ọjọ́ gbígbóná sórí àwọn eniyan burúkú; ìjì gbígbóná ni yóo sì jẹ́ ìpín wọn.

7 Nítorí olódodo ni OLUWA, ó sì fẹ́ràn òdodo; àwọn olóòótọ́ ni yóo rí ojú rẹ̀.

12

1 Gbani, OLUWA; nítorí àwọn olódodo kò sí mọ́; àwọn olóòótọ́ ti pòórá láàrin àwọn ọmọ eniyan.

2 Olukuluku ń purọ́ fún ẹnìkejì rẹ̀; ọ̀rọ̀ ìpọ́nni èké ati ẹ̀tàn ni wọ́n ń bá ara wọn sọ.

3 Kí OLUWA pa gbogbo àwọn tí ń fi èké pọ́nni run, ati àwọn tí ń fọ́nnu,

4 àwọn tí ń wí pé, “Ẹnu wa yìí ni a óo fi ṣẹgun, àwa la ni ẹnu wa; ta ni ó lè mú wa?”

5 OLUWA wí pé, “Nítorí ìnira àwọn aláìṣẹ̀, ati nítorí ìkérora àwọn tí à ń pọ́n lójú, n óo dìde nisinsinyii, n óo sì dáàbò bò wọ́n bí ọkàn wọn ti ń fẹ́.”

6 Ìlérí tó dájú ni ìlérí OLUWA, ó dàbí fadaka tí a yọ́ ninu iná ìléru amọ̀, tí a dà ninu iná nígbà meje.

7 Dáàbò bò wá, OLUWA, pa wá mọ́ laelae kúrò lọ́wọ́ irú àwọn eniyan báwọ̀nyí.

8 Àwọn eniyan burúkú ń yan kiri, níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan ń ṣe àpọ́nlé iṣẹ́ ibi.

13

1 Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA? Ṣé o óo wá gbàgbé mi laelae ni? Títí di ìgbà wo ni o óo fi ojú pamọ́ fún mi?

2 Títí di ìgbà wo ni ọkàn mi yóo gbọgbẹ́ tí ìbànújẹ́ yóo gba ọkàn mi kan, ní gbogbo ìgbà? Títí di ìgbà wo ni àwọn ọ̀tá mi yóo máa yọ̀ mí?

3 Bojúwò mí, kí o sì dá mi lóhùn, OLUWA, Ọlọrun mi. Tan ìmọ́lẹ̀ sí ojú mi, kí n má baà sun oorun ikú.

4 Kí ọ̀tá mi má baà wí pé, “Mo ti rẹ́yìn rẹ̀.” Kí àwọn tí ó kórìíra mi má baà yọ̀ bí mo bá ṣubú.

5 Ṣùgbọ́n èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀; n óo máa yọ̀ nítorí pé o óo gbà mí.

6 N óo máa kọrin sí ọ, OLUWA, nítorí o ṣeun fún mi lọpọlọpọ.

14

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò sí.” Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn, kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá, ó wo àwọn ọmọ eniyan, láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n, tí wọn ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ti ṣìnà, gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́; kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere, kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni? Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun, àwọn tí kì í ké pe OLUWA.

5 Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi, nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.

6 Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú, ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.

7 Ìbá ti dára tó kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá! Nígbà tí OLUWA bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada, Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

15

1 OLUWA, ta ni ó lè máa gbé inú àgọ́ rẹ? Ta ni ó lè máa gbé orí òkè mímọ́ rẹ?

2 Ẹni tí ń rìn déédéé, tí ń ṣe òdodo; tí sì ń fi tọkàntọkàn sọ òtítọ́.

3 Ẹni tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ eniyan lẹ́yìn, tí kò ṣe ibi sí ẹnìkejì rẹ̀, tí kò sì sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn nípa aládùúgbò rẹ̀.

4 Ẹni tí kò ka ẹni ẹ̀kọ̀ sí, ṣugbọn a máa bu ọlá fún àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA; bí ó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́, kì í yẹ̀ ẹ́; bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti wù kí ó nira tó.

5 Kì í yáni lówó kí ó gba èlé, kìí sìí gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́wọ́ aláìṣẹ̀. Ẹni tí ó bá ṣe nǹkan wọnyi, ẹsẹ̀ rẹ̀ kò ní yẹ̀ laelae.

16

1 Pa mí mọ́ Ọlọrun, nítorí ìwọ ni mo sá di.

2 Mo wí fún ọ, OLUWA, pé, “Ìwọ ni Oluwa mi; ìwọ nìkan ni orísun ire mi.”

3 Nípa àwọn eniyan mímọ́ tí ó wà nílẹ̀ yìí, wọ́n jẹ́ ọlọ́lá tí àwọn eniyan fẹ́ràn.

4 “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀: Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”

5 OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn; ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.

6 Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ; ogún rere ni ogún ti mo jẹ.

7 Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye; ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.

8 Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo, nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.

9 Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn; ara sì rọ̀ mí.

10 Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú, bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.

11 O ti fi ọ̀nà ìyè hàn mí; ayọ̀ kíkún ń bẹ ní iwájú rẹ, ìgbádùn àìlópin sì ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

17

1 Gbọ́ tèmi OLUWA, àre ni ẹjọ́ mi; fi ìtara gbọ́ igbe mi. Fetí sí adura mi nítorí kò sí ẹ̀tàn ní ẹnu mi.

2 Jẹ́ kí ìdáláre mi ti ọ̀dọ̀ rẹ wá; kí o sì rí i pé ẹjọ́ mi tọ́.

3 Yẹ ọkàn mi wò; bẹ̀ mí wò lóru. Dán mi wò, o kò ní rí ohun burúkú kan; n kò ní fi ẹnu mi dẹ́ṣẹ̀.

4 Nítorí ohun tí o wí nípa èrè iṣẹ́ ọwọ́ eniyan, mo ti yàgò fún àwọn oníwà ipá.

5 Mò ń tọ ọ̀nà rẹ tààrà; ẹsẹ̀ mi kò sì yọ̀.

6 Mo ké pè ọ́, dájúdájú ìwọ Ọlọrun yóo dá mi lóhùn, dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.

7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn lọ́nà ìyanu, fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó gbógun tì wọ́n.

8 Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú, dáàbò bò mí lábẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ;

9 lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú tí ó gbé ìjà kò mí, àní lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.

10 Ojú àánú wọn ti fọ́, ọ̀rọ̀ ìgbéraga sì ń ti ẹnu wọn jáde.

11 Wọn ń lépa mi; wọ́n sì ti yí mi ká báyìí; wọn ń ṣọ́ bí wọn ó ṣe bì mí ṣubú.

12 Wọ́n dàbí kinniun tí ó ṣetán láti pa ẹran jẹ, àní bí ọmọ kinniun tí ó ba ní ibùba.

13 Dìde, OLUWA! Dojú kọ wọ́n; là wọ́n mọ́lẹ̀; fi idà rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.

14 OLUWA, fi ọwọ́ ara rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan wọnyi; àwọn tí ìpín wọn jẹ́ ohun ti ayé yìí, fi ohun rere jíǹkí àwọn ẹni tí o pamọ́; jẹ́ kí àwọn ọmọ jẹ àjẹyó; sì jẹ́ kí àwọn ọmọ ọmọ wọn rí ogún wọn jẹ.

15 Ní tèmi, èmi óo rí ojú rẹ nítorí òdodo mi, ìrísí rẹ yóo sì tẹ́ mi lọ́rùn nígbà tí mo bá jí.

18

1 Mo fẹ́ràn rẹ, OLUWA, agbára mi.

2 OLUWA ni àpáta mi, ibi ààbò mi, ati olùgbàlà mi; Ọlọrun mi, àpáta mi, ninu ẹni tí ààbò mi wà. Òun ni asà mi, ìwo ìgbàlà mi ati ibi ìsásí mi.

3 Mo ké pe OLUWA, ẹni tí ìyìn yẹ, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

4 Ikú wé mọ́ mi bí okùn, ìparun sì bò mí mọ́lẹ̀ bíi rírú omi.

5 Isà òkú yí mi ká, tàkúté ikú sì dojú kọ mí.

6 Ninu ìpọ́njú mi mo ké pe OLUWA, Ọlọrun mi ni mo ké pè. Ó gbọ́ ohùn mi láti inú ilé mímọ́ rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí igbe mi.

7 Ilẹ̀ ayé wárìrì, ó sì mì tìtì, ìpìlẹ̀ àwọn òkè mì jìgìjìgì; wọ́n wárìrì nítorí tí ó bínú.

8 Èéfín ṣẹ́ jáde láti ihò imú rẹ̀, iná ajónirun yọ jáde láti ẹnu rẹ̀; ẹ̀yinná sì ń jò bùlà láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.

9 Ó dẹ ojú ọ̀run sílẹ̀, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá, ìkùukùu tó ṣókùnkùn biribiri sì wà lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.

10 Ó gun orí Kerubu, ó sì fò, ó fò lọ sókè lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.

11 Ó fi òkùnkùn bora bí aṣọ, ìkùukùu tí ó ṣókùnkùn, tí ó sì kún fún omi ni ó fi ṣe ìbòrí.

12 Ninu ìmọ́lẹ̀ níwájú rẹ, ẹ̀yinná ati yìnyín ń fọ́n jáde, láti inú ìkùukùu.

13 OLUWA sán ààrá láti ọ̀run, Ọ̀gá Ògo fọhùn, òjò dídì ati ẹ̀yinná sì fọ́n jáde.

14 Ó ta ọfà rẹ̀ jáde, ó sì fọ́n wọn ká, ó jẹ́ kí mànàmáná kọ, ó sì tú wọn ká.

15 Nígbà náà ni ìsàlẹ̀ òkun hàn ketekete, ìpìlẹ̀ ayé sì fojú hàn gbangba nítorí ìbáwí rẹ, OLUWA, ati nítorí agbára èémí ihò imú rẹ.

16 Ó nawọ́ láti òkè wá, ó sì dì mí mú, ó fà mí jáde láti inú ibú omi.

17 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi tí ó lágbára, ati lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi; nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.

18 Wọ́n gbógun tì mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi, ṣugbọn OLUWA ni aláfẹ̀yìntì mi.

19 Ó mú mi jáde wá síbi tí ó láàyè, ó yọ mí jáde nítorí tí inú rẹ̀ dùn sí mi.

20 OLUWA ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, bí ọwọ́ mi ṣe mọ́ ni ó ṣe pín mi lérè.

21 Nítorí tí mo ti pa ọ̀nà OLUWA mọ́, n kò ṣe ibi nípa yíyà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun mi.

22 Nítorí pé gbogbo òfin rẹ̀ ni mo tẹ̀lé, n kò sì yà kúrò ninu ìlànà rẹ̀.

23 Mo wà ní àìlẹ́bi níwájú rẹ̀, mo sì ti yẹra fún ẹ̀ṣẹ̀.

24 Nítorí náà ni OLUWA ṣe san án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ati gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ṣe mọ́ lójú rẹ̀.

25 Ò máa dúró ti àwọn tí ó dúró tì ọ́, ò sì máa ṣe àṣepé fún àwọn tí ó pé;

26 mímọ́ ni ọ́ sí àwọn tí ọkàn wọn mọ́, ṣugbọn àwọn alárèékérekè ni o fi ọgbọ́n tayọ.

27 Nítorí tí o máa ń gba àwọn onírẹ̀lẹ̀ là, ṣugbọn o máa ń rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀.

28 Nítorí ìwọ ni o mú kí àtùpà mi máa tàn, OLUWA, Ọlọrun mi ni ó tan ìmọ́lẹ̀ sí òkùnkùn mi.

29 Pẹlu ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, mo lè run ọ̀wọ́ àwọn ọmọ ogun, àní, pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọrun mi, mo lè fo odi ìlú.

30 Ní ti Ọlọrun, ọ̀nà rẹ̀ pé, pípé ni ọ̀rọ̀ OLUWA; òun sì ni ààbò fún gbogbo àwọn tí ó sá di í.

31 Ta tún ni Ọlọrun, bíkòṣe OLUWA? Àbí, ta ni àpáta, àfi Ọlọrun wa?

32 Ọlọrun tí ó gbé agbára wọ̀ mí, tí ó sì mú ọ̀nà mi pé.

33 Ó fi eré sí mi lẹ́sẹ̀ bíi ti àgbọ̀nrín, ó sì fún mi ní ààbò ní ibi ìsásí.

34 Ó kọ́ mi ní ogun jíjà tóbẹ́ẹ̀ tí mo fi lè fa ọrun idẹ.

35 O ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ, ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ó gbé mi ró, ìrànlọ́wọ́ rẹ sì ni ó sọ mí di ẹni ńlá.

36 O la ọ̀nà tí ó gbòòrò fún mi, n kò sì fi ẹsẹ̀ rọ́.

37 Mo lé àwọn ọ̀tá mi, ọwọ́ mi sì tẹ̀ wọ́n, n kò bojú wẹ̀yìn títí a fi pa wọ́n run.

38 Mo ṣá wọn lọ́gbẹ́, wọn kò lè dìde, wọ́n ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ mi.

39 O gbé agbára ogun wọ̀ mí; o sì mú àwọn tí ó dìde sí mi wólẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ mi.

40 O mú kí àwọn ọ̀tá mi máa sá níwájú mi, mo sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.

41 Wọ́n kígbe pé, “Ẹ gbà wá o!” Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n, wọ́n ké pe OLUWA, ṣugbọn kò dá wọn lóhùn.

42 Mo lọ̀ wọ́n lúbúlúbú bí eruku tí afẹ́fẹ́ ń gbá lọ, mo dà wọ́n nù bí ẹni da omi ẹrẹ̀ nù.

43 O gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tẹ̀ àwọn eniyan, o fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn orílẹ̀-èdè tí n kò mọ̀ rí sì ń sìn mí.

44 Bí wọ́n bá ti gbúròó mi ni wọ́n ń gbọ́ràn sí mi lẹ́nu; àwọn àjèjì ń fi ìbẹ̀rùbojo tẹríba, wọ́n ń wá ojurere mi.

45 Àyà pá àwọn àlejò, wọ́n sì fi ìbẹ̀rùbojo sá jáde kúrò ní ibi tí wọ́n sápamọ́ sí.

46 OLUWA wà láàyè! Ẹni ìyìn ni àpáta mi! Ẹni àgbéga ni Ọlọrun ìgbàlà mi!

47 Ọlọrun tí ó ń gbẹ̀san fún mi, tí ó sì ń tẹ orí àwọn eniyan ba fún mi;

48 Ọlọrun tí ó gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi; tí ó sì gbé mi ga ju àwọn abínú-ẹni lọ; ìwọ ni o gbà mí lọ́wọ́ àwọn ẹni ipá tí ó dìde sí mi.

49 Nítorí náà ni èmi ó ṣe máa yìn ọ́ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, OLUWA, èmi ó sì máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.

50 Ó fi ìṣẹ́gun ńlá fún ọba rẹ̀, ó sì fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ han ẹni àmì òróró rẹ̀, àní Dafidi ati ìrandíran rẹ̀ títí lae.

19

1 Ojú ọ̀run ń sọ̀rọ̀ ògo Ọlọrun, òfuurufú sì ń kéde iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

2 Ọjọ́ dé ọjọ́ ń sọ ọ́ ní àsọgbà òru dé òru sì ń fi ìmọ̀ rẹ̀ hàn.

3 Wọn kò fọ èdè kankan, wọn kò sì sọ ọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ohùn wọn;

4 sibẹ ìró wọn la gbogbo ayé já, ọ̀rọ̀ wọn sì dé òpin ayé. Ó pàgọ́ fún oòrùn lójú ọ̀run,

5 tí ó ń yọ jáde bí ọkọ iyawo tí ń jáde láti inú yàrá rẹ̀, ati bí akọni tí ara ń wá láti fi tayọ̀tayọ̀ sáré ìje.

6 Láti apá kan ojú ọ̀run ni ó ti ń yọ wá, a máa yípo gbogbo ojú ọ̀run dé apá keji; kò sì sí ohun tí ó bọ́ lọ́wọ́ ooru rẹ̀.

7 Òfin OLUWA pé, a máa sọ ọkàn jí; àṣẹ OLUWA dájú, ó ń sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8 Ìlànà OLUWA tọ́, ó ń mú ọkàn yọ̀, àṣẹ OLUWA péye, a máa lani lójú.

9 Ìbẹ̀rù OLUWA pé, ó wà títí lae, ìdájọ́ OLUWA tọ́, òdodo ni gbogbo wọn.

10 Wọ́n wuni ju wúrà lọ, àní ju ojúlówó wúrà lọ; wọ́n sì dùn ju oyin, àní, wọ́n dùn ju oyin tí ń kán láti inú afárá lọ.

11 Pẹlupẹlu àwọn ni wọ́n ń ki èmi iranṣẹ rẹ, nílọ̀, èrè pupọ sì ń bẹ ninu pípa wọ́n mọ́.

12 Ṣugbọn ta ni lè mọ àṣìṣe ara rẹ̀? Wẹ̀ mí mọ́ ninu àṣìṣe àìmọ̀ mi.

13 Pa èmi iranṣẹ rẹ mọ́ kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀-ọ́n-mọ̀-dá; má jẹ́ kí wọ́n jọba lórí mi. Nígbà náà ni ara mi yóo mọ́, n kò sì ní jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ati àṣàrò ọkàn mi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ, OLUWA ibi ààbò mi ati olùràpadà mi.

20

1 OLUWA óo dá ọ lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú, orúkọ Ọlọrun Jakọbu óo dáàbò bò ọ́.

2 Yóo rán olùrànlọ́wọ́ sí ọ láti ilé mímọ́ rẹ̀ wá, yóo sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3 Yóo ranti gbogbo ẹbọ ọrẹ rẹ, yóo sì gba ẹbọ sísun rẹ.

4 Yóo fún ọ ní ohun tí o fẹ́ ninu ọkàn rẹ, yóo sì mú gbogbo èrò rẹ ṣẹ.

5 Ìhó ayọ̀ ni a óo hó nígbà tí o bá ṣẹgun, ní orúkọ Ọlọrun wa ni a óo sì fi ọ̀págun wa sọlẹ̀; OLUWA yóo dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ.

6 Mo wá mọ̀ nisinsinyii pé OLUWA yóo ran ẹni àmì òróró rẹ̀ lọ́wọ́; OLUWA yóo dá a lóhùn láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá yóo sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fún un ní ìṣẹ́gun ńlá.

7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀lé kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin, ṣugbọn ní tiwa, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ OLUWA Ọlọrun wa.

8 Àwọn óo kọsẹ̀, wọn óo sì ṣubú, ṣugbọn àwa óo dìde, a óo sì dúró ṣinṣin.

9 Fún ọba ní ìṣẹ́gun, OLUWA; kí o sì dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń ké pè ọ́.

21

1 Ọba ń yọ̀ nítorí agbára rẹ, OLUWA; inú rẹ̀ ń dùn lọpọlọpọ nítorí ríràn tí o ràn án lọ́wọ́!

2 O ti fún un ní ohun tí ọkàn rẹ̀ ń fẹ́, o kò sì fi ohun tí ó ń tọrọ dù ú.

3 O gbé ibukun dáradára pàdé rẹ̀; o fi adé ojúlówó wúrà dé e lórí.

4 Ó bèèrè ẹ̀mí gígùn lọ́wọ́ rẹ; o fi fún un, àní, ọjọ́ gbọọrọ títí ayé.

5 Òkìkí rẹ̀ pọ̀ nítorí pé o ràn án lọ́wọ́; o sì fi iyì ati ọlá ńlá jíǹkí rẹ̀.

6 Nítòótọ́ o sọ ọ́ di ẹni ibukun títí lae; o sì mú kí inú rẹ̀ dùn nítorí pé o wà pẹlu rẹ̀.

7 Nítorí pé ọba gbẹ́kẹ̀lé OLUWA; a kò ní ṣí i ní ipò pada, nítorí ìfẹ́ Ọ̀gá Ògo tí kì í yẹ̀.

8 Ọwọ́ rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn tí ó kórìíra rẹ.

9 O óo jó wọn run bí iná ìléru, nígbà tí o bá yọ sí wọn. OLUWA yóo gbé wọn mì ninu ibinu rẹ̀; iná yóo sì jó wọn ní àjórun.

10 O óo pa àwọn ọmọ wọn run lórí ilẹ̀ ayé, o óo sì run ìran wọn láàrin àwọn eniyan.

11 Bí wọn bá gbèrò ibi sí ọ, tí wọ́n sì pète ìkà, wọn kò ní lè ṣe é.

12 Nítorí pé o óo lé wọn sá; nígbà tí o bá fi ọfà rẹ sun ojú wọn.

13 A gbé ọ ga, nítorí agbára rẹ, OLUWA! A óo máa kọrin, a óo sì máa yin agbára rẹ.

22

1 Ọlọrun mi, Ọlọrun mi, kí ló dé tí o fi kọ̀ mí sílẹ̀, tí o fi jìnnà sí mi, tí o kò gbọ́ igbe mi, kí o sì ràn mí lọ́wọ́?

2 Ọlọrun mi, mo kígbe pè ọ́ lọ́sàn-án, ṣugbọn o ò dáhùn; mo kígbe lóru, n ò sì dákẹ́.

3 Sibẹ Ẹni Mímọ́ ni ọ́, o gúnwà, Israẹli sì ń yìn ọ́.

4 Ìwọ ni àwọn baba wa gbẹ́kẹ̀lé; wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọ, o sì gbà wọ́n.

5 Wọ́n kígbe pè ọ́, o sì gbà wọ́n; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, ojú kò sì tì wọ́n.

6 Ṣugbọn kòkòrò lásán ni mí, n kì í ṣe eniyan; ayé kẹ́gàn mi, gbogbo eniyan sì ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà.

7 Gbogbo àwọn tí ó rí mi ní ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́; wọ́n ń yọ ṣùtì sí mi; wọ́n sì ń mi orí pé,

8 “Ṣebí OLUWA ni ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ lé lọ́wọ́; kí OLUWA ọ̀hún yọ ọ́, kí ó sì gbà á là, ṣebí inú rẹ̀ dùn sí i!”

9 Bẹ́ẹ̀ sì ni ìwọ ni o mú mi jáde láti inú ìyá mi; ìwọ ni o sì mú mi wà láìséwu nígbà tí mo wà ní ọmọ ọmú.

10 Ìwọ ni wọ́n bí mi lé lọ́wọ́; ìwọ ni Ọlọrun mi láti ìgbà tí ìyá mi ti bí mi.

11 Má jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu wà nítòsí, kò sì sí ẹni tí yóo ràn mí lọ́wọ́.

12 Àwọn ọ̀tá yí mi ká bí akọ mààlúù, wọ́n yí mi ká bí akọ mààlúù Baṣani tó lágbára.

13 Wọ́n ya ẹnu wọn sí mi bí kinniun, bí kinniun tí ń dọdẹ kiri tí ń bú ramúramù.

14 Agbára mi ti lọ, ó ti ṣàn dànù bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ lóríkèéríkèé; ọkàn mi dàbí ìda, ó ti yọ́.

15 Okun inú mi ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mi sì ti lẹ̀ mọ́ mi lẹ́nu; o ti fi mí sílẹ̀ sinu eruku isà òkú.

16 Àwọn eniyan burúkú yí mi ká bí ajá; àwọn aṣebi dòòyì ká mi; wọ́n fa ọwọ́ ati ẹsẹ̀ mi ya.

17 Mo lè ka gbogbo egungun mi wọ́n tẹjúmọ́ mi; wọ́n ń fojú burúkú wò mí.

18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrin ara wọn, wọ́n ṣẹ́ gègé nítorí ẹ̀wù mi.

19 Ṣugbọn ìwọ, OLUWA, má jìnnà sí mi! Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi, ṣe gírí láti ràn mí lọ́wọ́!

20 Gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ idà, gbà mí lọ́wọ́ àwọn ajá!

21 Já mi gbà kúrò lẹ́nu kinniun nnì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwo ẹhànnà mààlúù!

22 N óo ròyìn orúkọ rẹ fún àwọn ará mi; láàrin àwùjọ àwọn eniyan ni n óo sì ti máa yìn ọ́:

23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ máa yìn ín! Ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, ẹ fi ògo fún un, ẹ dúró tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ níwájú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin ọmọ Israẹli!

24 Nítorí pé kò fi ojú pa ìjìyà àwọn tí à ń jẹ níyà rẹ́; kò sì ṣá wọn tì, bẹ́ẹ̀ ni kò fi ojú pamọ́ fún wọn, ṣugbọn ó gbọ́ nígbà tí wọ́n ké pè é.

25 Ìwọ ni n óo máa yìn láàrin àwùjọ àwọn eniyan; n óo san ẹ̀jẹ́ mi láàrin àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA.

26 Àwọn tí ojú ń pọ́n yóo jẹ àjẹyó; àwọn tí ń wá OLUWA yóo yìn ín! Kí ẹ̀mí wọn ó gùn!

27 Gbogbo ayé ni yóo ranti OLUWA wọn yóo sì pada sọ́dọ̀ rẹ̀; gbogbo ẹ̀yà àwọn orílẹ̀-èdè ni yóo sì júbà níwájú rẹ̀.

28 Nítorí OLUWA ló ni ìjọba, òun ní ń jọba lórí gbogbo orílẹ̀-èdè.

29 Gbogbo àwọn agbéraga láyé ni yóo wólẹ̀ níwájú rẹ̀; gbogbo ẹni tí yóo fi ilẹ̀ bora bí aṣọ ni yóo wólẹ̀ níwájú rẹ̀, àní, gbogbo àwọn tí kò lè dá sọ ara wọn di alààyè.

30 Ìran tí ń bọ̀ yóo máa sìn ín; àwọn eniyan yóo máa sọ̀rọ̀ OLUWA fún àwọn ìran tí ń bọ̀.

31 Wọn óo máa kéde ìgbàlà rẹ̀ fún àwọn ọmọ tí a kò tíì bí, pé, “OLUWA ló ṣe é.”

23

1 OLUWA ni Olùṣọ́-aguntan mi, n kò ní ṣe àìní ohunkohun.

2 Ó mú mi dùbúlẹ̀ ninu pápá koríko tútù, ó mú mi lọ sí ibi tí omi ti dákẹ́ rọ́rọ́;

3 ó sọ agbára mi dọ̀tun. Ó tọ́ mi sí ọ̀nà òdodo nítorí orúkọ rẹ̀.

4 Àní, bí mo tilẹ̀ ń rìn ninu òkùnkùn létí bèbè ikú, n kò ní bẹ̀rù ibi kankan; nítorí tí o wà pẹlu mi; ọ̀gọ rẹ ati ọ̀pá rẹ ń fi mí lọ́kàn balẹ̀.

5 O gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú mi, níṣojú àwọn ọ̀tá mi; o da òróró sí mi lórí; o sì bu ife mi kún ní àkúnwọ́sílẹ̀.

6 Dájúdájú, ire ati àánú yóo máa tẹ̀lé mi kiri, ní gbogbo ọjọ́ ayé mi; èmi óo sì máa gbé inú ilé OLUWA laelae.

24

1 OLUWA ló ni ilẹ̀ ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀, òun ló ni ayé, ati gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀;

2 nítorí pé òun ló fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí òkun, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí ìṣàn omi.

3 Ta ló lè gun orí òkè OLUWA lọ? Ta ló sì lè dúró ninu ibi mímọ́ rẹ̀?

4 Ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ mọ́, tí inú rẹ̀ sì funfun, tí kò gbẹ́kẹ̀lé oriṣa lásánlàsàn, tí kò sì búra èké.

5 Òun ni yóo rí ibukun gbà lọ́dọ̀ OLUWA, tí yóo sì rí ìdáláre gbà lọ́wọ́ Ọlọrun, Olùgbàlà rẹ̀.

6 Irú wọn ni àwọn tí ń wá OLUWA, àní àwọn tí ń wá ojurere Ọlọrun Jakọbu.

7 Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn, ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo lè wọlé.

8 Ta ni Ọba ògo yìí? OLUWA tí ó ní ipá tí ó sì lágbára, OLUWA tí ó lágbára lógun.

9 Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn, ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo lè wọlé.

10 Ta ni Ọba ògo yìí? OLUWA àwọn ọmọ ogun, òun ni Ọba ògo náà.

25

1 OLUWA, ìwọ ni mo gbé ojú ẹ̀bẹ̀ sókè sí.

2 Ọlọrun mi, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé, má jẹ́ kí ojú ó tì mí; má jẹ́ kí ọ̀tá ó yọ̀ mí.

3 OLUWA, má jẹ́ kí ojú ó ti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọ; àwọn ọ̀dàlẹ̀ eniyan ni kí ojú ó tì.

4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, OLUWA, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ.

5 Tọ́ mi sí ọ̀nà òtítọ́ rẹ, sì máa kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọrun olùgbàlà mi; ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé ní ọjọ́ gbogbo.

6 OLUWA, ranti àánú rẹ, ati ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, nítorí wọ́n ti wà ọjọ́ ti pẹ́.

7 Má ranti ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ti ṣẹ̀ ní ìgbà èwe mi, tabi ibi tí mo ti kọjá ààyè mi; ranti mi, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, ati nítorí oore rẹ.

8 Olóore ati olódodo ni OLÚWA, nítorí náà ni ó ṣe ń fi ọ̀nà han àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

9 A máa tọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́, a sì máa kọ́ wọn ní ìlànà rẹ̀.

10 Gbogbo ọ̀nà OLUWA ni ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́, fún àwọn tí ń pa majẹmu ati òfin rẹ̀ mọ́.

11 Nítorí orúkọ rẹ, OLUWA, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí mo jẹ̀bi lọpọlọpọ.

12 Ẹni tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni OLUWA yóo kọ́ ní ọ̀nà tí yóo yàn.

13 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóo sì jogún ilẹ̀ náà.

14 Àwọn tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni OLUWA ń mú ní ọ̀rẹ́, a sì máa fi majẹmu rẹ̀ hàn wọ́n.

15 OLUWA ni mò ń wò lójú nígbà gbogbo, nítorí òun ni yóo yọ ẹsẹ̀ mi kúrò ninu àwọ̀n.

16 Kọjú sí mi kí o sì ṣàánú mi; nítorí n kò lẹ́nìkan, ojú sì ń pọ́n mi.

17 Mú ìdààmú ọkàn mi kúrò; kí o sì yọ mí ninu gbogbo ìpọ́njú mi.

18 Wo ìpọ́njú ati ìdààmú mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí.

19 Wo iye ọ̀tá tí èmi nìkan ní, ati irú ìkórìíra ìkà tí wọ́n kórìíra mi.

20 Pa mí mọ́, kí o sì gbà mí; má jẹ́ kí ojú kí ó tì mí, nítorí ìwọ ni mo sá di.

21 Nítorí pípé mi ati òdodo mi, pa mí mọ́, nítorí pé ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé.

22 Ọlọrun, ra Israẹli pada, kúrò ninu gbogbo ìyọnu rẹ̀.

26

1 Dá mi láre, OLUWA, nítorí ninu ìwà pípé ni mò ń rìn, mo sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA láìṣiyèméjì.

2 Yẹ̀ mí wò, OLUWA, dán mi wò; yẹ inú mi wò, sì ṣe akiyesi ọkàn mi.

3 Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni mo tẹjúmọ́, mo sì ń fi òtítọ́ bá ọ rìn.

4 N kò jókòó ti àwọn èké, n kò sì gba ìmọ̀ràn àwọn ẹlẹ́tàn;

5 mo kórìíra wíwà pẹlu àwọn aṣebi, n kò sì jẹ́ bá àwọn eniyan burúkú da nǹkan pọ̀.

6 Ọwọ́ mi mọ́, n kò ní ẹ̀bi, OLUWA, mo sì ń jọ́sìn yí pẹpẹ rẹ ká.

7 Mò ń kọ orin ọpẹ́ sókè, mo sì ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ.

8 OLUWA, mo fẹ́ràn ilé rẹ, tí ò ń gbé, ati ibi tí ògo rẹ wà.

9 Má pa mí run pẹlu àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, má sì gba ẹ̀mí mi pẹlu ti àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ ìpànìyàn,

10 àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún iṣẹ́ ibi, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

11 Ṣugbọn ní tèmi, èmi ń rìn ninu ìwà pípé; rà mí pada, kí o sì ṣàánú mi.

12 Mo dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú; láwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan ni n óo máa yin OLUWA.

27

1 OLUWA ni ìmọ́lẹ̀ ati ìgbàlà mi; ta ni n óo bẹ̀rù? OLUWA ni ààbò ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóo bà mí?

2 Nígbà tí àwọn aṣebi bá ń gbógun bọ̀ wá bá mi, tí wọ́n fẹ́ pa mí, àwọn alátakò ati àwọn ọ̀tá mi, wọn óo kọsẹ̀, wọn óo sì ṣubú.

3 Bí ogun tilẹ̀ dó tì mí àyà mi kò ní já. Bí wọ́n tilẹ̀ gbé ogun wá bá mi, sibẹ, ọkàn mi kò ní mì.

4 Ohun kan ni mo ti tọrọ lọ́dọ̀ OLUWA, òun ni n óo sì máa lépa: Kí n lè máa gbé inú ilé OLUWA ní gbogbo ọjọ́ ayé mi, kí n lè máa wo ẹwà OLUWA, kí n sì máa fi tọkàntọkàn sìn ín ninu tẹmpili rẹ̀.

5 Nítorí pé, nígbà tí ìpọ́njú bá dé, yóo fi mí pamọ́ sinu àgọ́ rẹ̀, lábẹ́ ààbò, ninu àgọ́ rẹ̀, ni yóo fi mí pamọ́ sí; yóo sì gbé mi sókè ka orí àpáta.

6 Nisinsinyii n óo ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá mi tí ó yí mi ká; n óo rúbọ ninu àgọ́ rẹ̀ pẹlu ìhó ayọ̀, n óo sì kọ orin aládùn sí OLUWA.

7 Gbọ́ OLUWA, nígbà tí mo bá ń kígbe pè ọ́; ṣàánú mi kí o sì dá mi lóhùn.

8 Nígbà tí o wí pé, “Ẹ máa wá ojú mi.” Ọkàn mi dá ọ lóhùn pé, “Ojú rẹ ni n óo máa wá, OLUWA,

9 má fi ojú pamọ́ fún mi!” Má fi ibinu lé èmi iranṣẹ rẹ kúrò, ìwọ tí o ti ń ràn mí lọ́wọ́, má ta mí nù, má sì ṣá mi tì, Ọlọrun ìgbàlà mi.

10 Bí baba ati ìyá mi tilẹ̀ kọ̀ mí sílẹ̀, OLUWA yóo tẹ́wọ́gbà mí.

11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, OLUWA, kí o sì tọ́ mi sí ọ̀nà títẹ́jú rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi.

12 Má fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́; nítorí pé àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde sí mi, ètè wọn sì kún fún ọ̀rọ̀ ìkà.

13 Mo gbàgbọ́ pé n óo rí oore OLUWA gbà ní ilẹ̀ alààyè.

14 Dúró de OLUWA, ṣe bí akin, kí o sì mú ọkàn gírí, àní, dúró de OLUWA.

28

1 Ìwọ ni mo kígbe pè, OLUWA, ìwọ ni ààbò mi, má di etí sí mi. Nítorí bí o bá dákẹ́ sí mi n óo dàbí àwọn òkú, tí wọ́n ti lọ sinu kòtò.

2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, bí mo ti ń kígbe sí ọ pé kí o ràn mí lọ́wọ́; tí mo gbé ọwọ́ mi sókè sí ìhà ilé mímọ́ rẹ.

3 Má ṣe kó mi lọ pẹlu àwọn eniyan burúkú, pẹlu àwọn tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, àwọn tí ń bá àwọn aládùúgbò wọn sọ ọ̀rọ̀ alaafia, ṣugbọn tí ètekéte ń bẹ ninu ọkàn wọn.

4 San án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn, àní gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ burúkú wọn; san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn, fún wọn ní èrè tí ó tọ́ sí wọn.

5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ OLUWA sí, wọn kò sì bìkítà fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, OLUWA yóo sọ wọ́n di ilẹ̀, kò sì ní gbé wọn dìde mọ́.

6 Ẹni ìyìn ni OLUWA! Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7 OLUWA ni agbára ati asà mi, òun ni mo gbẹ́kẹ̀lé; ó ràn mí lọ́wọ́, ọkàn mi sì kún fún ayọ̀; mo sì fi orin ìyìn dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

8 OLUWA ni agbára àwọn eniyan rẹ̀; òun ni ààbò ìgbàlà fún ẹni àmì òróró rẹ̀.

9 Gba àwọn eniyan rẹ là, OLUWA, kí o sì bukun ilẹ̀ ìní rẹ. Jẹ́ olùṣọ́-aguntan wọn, kí o sì máa tọ́jú wọn títí lae.

29

1 Ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi ògo fún OLUWA, ẹ gbé agbára rẹ̀ lárugẹ.

2 Ẹ fún OLUWA ní ògo tí ó yẹ orúkọ rẹ̀, ẹ máa sin OLUWA ninu ẹwà mímọ́ rẹ̀.

3 À ń gbọ́ ohùn OLUWA lójú omi òkun, Ọlọrun ológo ń sán ààrá, Ọlọrun ń sán ààrá lójú alagbalúgbú omi.

4 Ohùn OLUWA lágbára, ohùn OLUWA kún fún ọlá ńlá.

5 Ohùn OLUWA ń fọ́ igi kedari, OLUWA ń fọ́ igi kedari ti Lẹbanoni.

6 Ó ń mú kí òkè Lẹbanoni ta pọ́núnpọ́nún bí ọmọ mààlúù, ó sì mú kí òkè Sirioni máa fò bí akọ ọmọ mààlúù-igbó.

7 Ohùn OLUWA ń yọ iná lálá.

8 Ohùn OLUWA ń mi aṣálẹ̀; OLUWA ń mi aṣálẹ̀ Kadeṣi.

9 Ohùn OLUWA a máa mú abo àgbọ̀nrín bí, a máa wọ́ ewé lára igi oko; gbogbo eniyan ń kígbe ògo rẹ̀ ninu Tẹmpili rẹ̀.

10 OLUWA jókòó, ó gúnwà lórí ìkún omi; OLUWA jókòó, ó gúnwà bí ọba títí lae.

11 OLUWA yóo fún àwọn eniyan rẹ̀ ní agbára; OLUWA yóo fún wọn ní ibukun alaafia.

30

1 N óo yìn ọ́, OLUWA, nítorí pé o ti yọ mí jáde; o kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.

2 OLUWA, Ọlọrun mi, mo ké pè ọ́, o sì wò mí sàn.

3 OLUWA, o ti yọ mí kúrò ninu isà òkú o sọ mí di ààyè láàrin àwọn tí wọ́n ti wọ inú kòtò.

4 Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA, ẹ̀yin olùfọkànsìn rẹ̀, kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ̀.

5 Nítorí pé fún ìgbà díẹ̀ ni ibinu rẹ̀, ṣugbọn títí ayé ni ojurere rẹ̀; eniyan lè máa sọkún títí di alẹ́, ṣugbọn ayọ̀ ń bọ̀ fún un lówùúrọ̀.

6 Nígbà tí ara rọ̀ mí, mo wí ninu ọkàn mi pé, kò sí ohun tí ó lè mì mí laelae.

7 Nípa ojurere rẹ, OLUWA, o ti fi ìdí mi múlẹ̀ bí òkè ńlá; ṣugbọn nígbà tí o fi ojú pamọ́ fún mi, ìdààmú dé bá mi.

8 Ìwọ ni mò ń ké pè, OLUWA, OLUWA, ìwọ ni mò ń bẹ̀.

9 Anfaani wo ló wà ninu pé kí n kú? Èrè wo ló wà ninu pé kí n wọ inú kòtò? Ṣé erùpẹ̀ lè yìn ọ́? Ṣé ó lè sọ nípa òdodo rẹ?

10 Gbọ́ OLUWA, kí o sì ṣàánú mi, OLUWA, ràn mí lọ́wọ́.

11 O ti bá mi sọ ọ̀fọ̀ mi di ijó, o ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò lára mi, o sì ti dì mí ní àmùrè ayọ̀,

12 kí ọkàn mi lè máa yìn ọ́ láìdákẹ́. OLUWA Ọlọrun mi, n óo máa fi ọpẹ́ fún ọ títí lae.

31

1 OLUWA, ìwọ ni mo sá di, má jẹ́ kí ojú tì mí lae; gbà mí, nítorí olóòótọ́ ni ọ́.

2 Dẹ etí sí mi, yára gbà mí. Jẹ́ àpáta ààbò fún mi; àní ilé ààbò tó lágbára láti gbà mí là.

3 Ìwọ ni àpáta ati ilé ààbò mi; nítorí orúkọ rẹ, máa tọ́ mi kí o sì máa fọ̀nà hàn mí.

4 Yọ mí kúrò ninu àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ dè mí, nítorí ìwọ ni ẹni ìsádi mi.

5 Ìwọ ni mo fi ẹ̀mí mi lé lọ́wọ́, o ti rà mí pada, OLUWA, Ọlọrun, olóòótọ́.

6 Mo kórìíra àwọn tí ń bọ oriṣa lásánlàsàn, ṣugbọn OLUWA ni èmi gbẹ́kẹ̀lé.

7 N óo máa yọ̀, inú mi óo sì máa dùn, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀; nítorí pé o ti rí ìpọ́njú mi, o sì mọ ìṣòro mi.

8 O ò fi mí lé ọ̀tá lọ́wọ́, o sì ti fi ẹsẹ̀ mi lé ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.

9 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí pé mo wà ninu ìṣòro. Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì; àárẹ̀ sì mú ọkàn ati ara mi.

10 Nítorí pé ìbànújẹ́ ni mo fi ń lo ayé mi; ìmí ẹ̀dùn ni mo sì fi ń lo ọdún kan dé ekeji. Ìpọ́njú ti gba agbára mi; gbogbo egungun mi sì ti di hẹ́gẹhẹ̀gẹ.

11 Ẹni ẹ̀gàn ni mí láàrin gbogbo àwọn ọ̀tá mi, àwòsọkún ni mí fún àwọn aládùúgbò. Mo di àkòtagìrì fún àwọn ojúlùmọ̀ mi, àwọn tí ó rí mi lóde sì ń sá fún mi.

12 Mo di ẹni ìgbàgbé bí ẹni tí ó ti kú; mo dàbí àkúfọ́ ìkòkò.

13 Mò ń gbọ́ tí ọ̀pọ̀ eniyan ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, bí wọ́n ti ń gbìmọ̀ pọ̀ nípa mi, tí wọ́n sì ń pète ati pa mí; wọ́n ń ṣẹ̀rù bà mí lọ́tùn-ún lósì.

14 Ṣugbọn, mo gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA, Mo ní, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.”

15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ; gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

16 Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ, gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

17 Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA, nítorí ìwọ ni mò ń ké pè. Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú; jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.

18 Jẹ́ kí àwọn òpùrọ́ yadi, àní àwọn tí ń fi ìgbéraga ati ẹ̀gàn sọ̀rọ̀ àìdára nípa olódodo.

19 Háà! Ohun rere mà pọ̀ lọ́wọ́ rẹ o tí o ti sọ lọ́jọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, tí o sì ti pèsè ní ìṣojú àwọn ọmọ eniyan, fún àwọn tí ó sá di ọ́.

20 O fi ìyẹ́ apá rẹ ṣíji bò wọ́n; o pa wọ́n mọ́ kúrò ninu rìkíṣí àwọn eniyan; o sì pa wọ́n mọ́ lábẹ́ ààbò rẹ, kúrò lọ́wọ́ ẹnu àwọn ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.

21 Ẹni ìyìn ni OLUWA, nítorí pé, lọ́nà ìyanu, ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn mí, nígbà tí ilẹ̀ ká mi mọ́.

22 Ẹ̀rù bà mí, mo sì sọ pé, “A lé mi jìnnà kúrò ní iwájú rẹ.” Ṣugbọn o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.

23 Ẹ fẹ́ràn OLUWA, gbogbo ẹ̀yin olódodo, OLUWA a máa ṣọ́ àwọn olóòótọ́, a sì máa san àlékún ẹ̀san fún àwọn agbéraga.

24 Ẹ múra gírí, kí ẹ sì mọ́kàn le, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

32

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí a dárí ìrékọjá rẹ̀ jì, tí a bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀.

2 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí OLUWA kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn, tí ẹ̀tàn kò sì sí ninu ọkàn rẹ̀.

3 Nígbà tí n kò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi, ó rẹ̀ mí wá láti inú, nítorí kíkérora tí mò ń kérora ní gbogbo ìgbà.

4 Nítorí tọ̀sán-tòru ni o fi ń jẹ mí níyà; gbogbo agbára mi ló lọ háú, bí omi tíí gbẹ lákòókò ẹ̀ẹ̀rùn.

5 Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ; n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ. Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,” o sì dáríjì mí.

6 Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ; ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá, kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

7 Ìwọ ni ibi ìsásí mi; o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro; o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

8 N óo kọ́ ọ, n óo sì tọ́ ọ sí ọ̀nà tí o óo rìn; n óo máa gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn; n óo sì máa mójútó ọ.

9 Má ṣe dàbí ẹṣin tabi ìbaaka, tí kò ni ọgbọ́n ninu, tí a gbọdọ̀ kó ìjánu sí lẹ́nu kí ó tó lè gbọ́ ti oluwa rẹ̀.

10 Ìrora pọ̀ fún àwọn eniyan burúkú, ṣugbọn ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ni ó yí àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA ká.

11 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA; ẹ fò fún ayọ̀, ẹ̀yin olódodo; kí ẹ sì hó fún ayọ̀, gbogbo ẹ̀yin ọlọ́kàn mímọ́.

33

1 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo! Yíyin OLUWA ni ó yẹ ẹ̀yin olóòótọ́.

2 Ẹ fi gòjé yin OLUWA, ẹ fi hapu olókùn mẹ́wàá kọ orin sí i.

3 Ẹ kọ orin titun sí i, ẹ fi ohun èlò ìkọrin olókùn dárà, kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀.

4 Nítorí ọ̀rọ̀ OLUWA dúró ṣinṣin; òtítọ́ sì ni ó fi ń ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.

5 OLUWA fẹ́ràn òdodo ati ẹ̀tọ́; ayé kún fún ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

6 Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run, èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.

7 Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì; ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.

8 Kí gbogbo ayé bẹ̀rù OLUWA, kí gbogbo aráyé dúró níwájú rẹ̀ pẹlu ọ̀wọ̀ ati ìbẹ̀rù!

9 Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà; ó pàṣẹ, ayé sì dúró.

10 OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán; ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.

11 Ètò OLUWA wà títí lae, èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

12 Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn, àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!

13 OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run, ó rí gbogbo eniyan;

14 láti orí ìtẹ́ rẹ̀ tí ó gúnwà sí, ó wo gbogbo aráyé.

15 Òun ni ó dá ọkàn gbogbo wọn, tí ó sì ń mójútó gbogbo ìṣe wọn.

16 Kì í ṣe pípọ̀ tí àwọn ọmọ ogun pọ̀ ní ń gba ọba là; kì í sì í ṣe ọ̀pọ̀ agbára níí gba jagunjagun là.

17 Asán ni igbẹkẹle agbára ẹṣin ogun; kìí ṣe agbára tí ẹṣin ní, ló lè gbani là.

18 Wò ó! OLUWA ń ṣọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àní àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,

19 kí ó lè gba ọkàn wọn lọ́wọ́ ikú, kí ó sì mú wọn wà láàyè lákòókò ìyàn.

20 Ọkàn wa ní ìrètí lọ́dọ̀ OLUWA; òun ni olùrànlọ́wọ́ ati ààbò wa.

21 A láyọ̀ ninu rẹ̀, nítorí pé a gbẹ́kẹ̀lé orúkọ mímọ́ rẹ̀.

22 OLUWA, jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà lórí wa bí a ti gbẹ́kẹ̀lé ọ.

34

1 N óo máa yin OLUWA ní gbogbo ìgbà; ìyìn rẹ̀ yóo máa wà ní ẹnu mi nígbà gbogbo.

2 OLUWA ni èmi óo máa fi yangàn; kí inú àwọn olùpọ́njú máa dùn nígbà tí wọ́n bá gbọ́.

3 Ẹ bá mi gbé OLUWA ga, ẹ jẹ́ kí á jùmọ̀ gbé orúkọ rẹ̀ lékè!

4 Mo ké pe OLUWA, ó sì dá mi lóhùn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ gbogbo ohun tí ń bà mí lẹ́rù.

5 Wọ́n gbójú sókè sí OLUWA, wọ́n láyọ̀; ojú kò sì tì wọ́n.

6 Olùpọ́njú ké pe OLUWA, OLUWA gbọ́ ohùn rẹ̀, ó sì gbà á ninu gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.

7 Angẹli OLUWA yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká, a sì máa gbà wọ́n.

8 Tọ́ ọ wò, kí o sì rí i pé rere ni OLUWA! Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá sá di í!

9 Ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ̀yin eniyan mímọ́ rẹ̀, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀!

10 Àwọn ọmọ kinniun a máa ṣe aláìní, ebi a sì máa pa wọ́n; ṣugbọn àwọn tí wọ́n bá ń wá OLUWA kò ní ṣe aláìní ohun rere kankan.

11 Ẹ wá, ẹ̀yin ọmọ, ẹ tẹ́tí sí mi, n óo kọ yín ní ìbẹ̀rù OLUWA.

12 Ta ni ń fẹ́ ìyè ninu yín, tí ń fẹ́ ẹ̀mí gígùn, tí ó fẹ́ pẹ́ láyé?

13 Ẹ ṣọ́ ẹnu yín, ẹ má sọ̀rọ̀ burúkú, ẹ má sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ti ẹnu yín jáde.

14 Ẹ yàgò fún ibi, rere ni kí ẹ máa ṣe; ẹ máa wá alaafia, kí ẹ sì máa lépa rẹ̀.

15 OLUWA ń ṣọ́ àwọn olódodo, Ó sì ń dẹ etí sí igbe wọn.

16 OLUWA fojú sí àwọn aṣebi lára, láti pa wọ́n rẹ́, kí á má sì ṣe ranti wọn mọ́ lórí ilẹ̀ ayé.

17 Nígbà tí olódodo bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́, OLUWA a máa gbọ́, a sì máa gbà wọ́n kúrò ninu gbogbo ìyọnu wọn.

18 OLUWA wà nítòsí àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́, a sì máa gba àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn là.

19 Ìpọ́njú olódodo a máa pọ̀; ṣugbọn OLUWA a máa kó o yọ ninu gbogbo wọn.

20 A máa pa gbogbo egungun rẹ̀ mọ́; kì í jẹ́ kí ọ̀kankan fọ́ ninu wọn.

21 Ibi ni yóo pa eniyan burúkú; a óo sì dá àwọn tí ó kórìíra olódodo lẹ́bi.

22 OLUWA ra ẹ̀mí àwọn iranṣẹ rẹ̀ pada; ẹnikẹ́ni tí ó bá sá di í kò ní jẹ̀bi.

35

1 OLUWA, gbógun ti àwọn tí ń gbógun tì mí; gbé ìjà ko àwọn tí ń bá mi jà!

2 Gbá asà ati apata mú, dìde, kí o sì ràn mí lọ́wọ́!

3 Fa ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojú kọ àwọn tí ń lépa mi! Ṣe ìlérí fún mi pé, ìwọ ni olùgbàlà mi.

4 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi, kí wọn ó tẹ́! Jẹ́ kí àwọn tí ń gbìmọ̀ ibi sí mi dààmú, kí wọ́n sì sá pada sẹ́yìn!

5 Kí wọ́n dàbí fùlùfúlù ninu afẹ́fẹ́, kí angẹli OLUWA máa lé wọn lọ!

6 Jẹ́ kí ojú ọ̀nà wọn ṣóòkùn, kí ó sì máa yọ̀, kí angẹli OLUWA máa lépa wọn!

7 Nítorí wọ́n dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún mi láìnídìí, wọ́n sì gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí láìnídìí.

8 Jẹ́ kí ìparun dé bá wọn lójijì, jẹ́ kí àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ dè mí mú wọn; jẹ́ kí wọ́n kó sinu rẹ̀, kí wọ́n sì parun!

9 Nígbà náà ni n óo máa yọ̀ ninu OLUWA, n óo sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìgbàlà rẹ̀.

10 N óo fi gbogbo ara wí pé, “OLUWA, ta ni ó dàbí rẹ? Ìwọ ni ò ń gba aláìlágbára lọ́wọ́ ẹni tí ó lágbára tí o sì ń gba aláìlágbára ati aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ó fẹ́ fi wọ́n ṣe ìjẹ.”

11 Àwọn tí ń fi ìlara jẹ́rìí èké dìde sí mi; wọ́n ń bi mí léèrè ohun tí n kò mọ̀dí.

12 Wọ́n fi ibi san oore fún mi, ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.

13 Bẹ́ẹ̀ sì ni, ní tèmi, nígbà tí wọn ń ṣàìsàn, aṣọ ọ̀fọ̀ ni mo wọ̀; mo fi ààwẹ̀ jẹ ara mi níyà; mo gbadura pẹlu ìtẹríba patapata,

14 bí ẹni pé mò ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀rẹ́ mi, tabi arakunrin mi; mò ń lọ káàkiri, bí ẹni tí ń pohùnréré ẹkún ìyá rẹ̀, mo doríkodò, mo sì ń ṣọ̀fọ̀.

15 Ṣugbọn nígbà tí èmi kọsẹ̀, wọ́n kó ara wọn jọ, wọ́n ń yọ̀, wọ́n kó tì mí; pàápàá jùlọ, àwọn àlejò tí n kò mọ̀ rí bẹ̀rẹ̀ sí purọ́ mọ́ mi léraléra.

16 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí pẹ̀gàn mi, wọ́n ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n sì ń wò mí bíi pé kí n kú.

17 OLUWA, yóo ti pẹ́ tó, tí o óo máa wò mí níran? Yọ mí kúrò ninu ogun tí wọn gbé tì mí, gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn kinniun!

18 Nígbà náà ni n óo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ láàrin àwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan; láàrin ọpọlọpọ eniyan ni n óo máa yìn ọ́.

19 Má jẹ́ kí àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí yọ̀ mí, má sì jẹ́ kí àwọn tí ó kórìíra mi wò mí ní ìwò ẹ̀sín.

20 Nítorí pé wọn kì í sọ̀rọ̀ alaafia sí àwọn tí wọn ń lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọn àfi kí wọ́n máa pète oríṣìíríṣìí ẹ̀tàn.

21 Wọ́n la ẹnu, wọ́n ń pariwo lé mi lórí, wọ́n ń wí pé, “Ìn hín ìn, a rí ọ, ojú wa ló ṣe!”

22 O ti rí i, OLUWA, má dákẹ́. OLUWA, má jìnnà sí mi.

23 Paradà, OLUWA, jí gìrì sí ọ̀ràn mi, gbèjà mi, Ọlọrun mi, ati OLUWA mi!

24 Dá mi láre, OLUWA, Ọlọrun mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ; má sì jẹ́ kí wọ́n yọ̀ mí!

25 Má jẹ́ kí wọ́n wí láàrin ara wọn pé, “Ìn hín ìn, ọwọ́ wa ba ohun tí a fẹ́!” Má jẹ́ kí wọn wí pé, “A rẹ́yìn ọ̀tá wa.”

26 Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí ń yọ̀ pé ìpọ́njú dé bá mi; kí ìdààmú bá wọn; bá mi da aṣọ ìtìjú ati ẹ̀tẹ́ bo àwọn tí ń gbé àgbéré sí mi.

27 Kí àwọn tí ń wá ìdáláre mi máa hó ìhó ayọ̀, kí inú wọn sì máa dùn, kí wọ́n máa wí títí ayé pé, “OLUWA tóbi, inú rẹ̀ dùn sí alaafia àwọn iranṣẹ rẹ̀.”

28 Nígbà náà ni n óo máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ, n óo sì máa yìn ọ́ tọ̀sán-tòru.

36

1 Ẹ̀ṣẹ̀ ń gbin lọ́kàn eniyan burúkú, kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ninu èrò tirẹ̀.

2 Nítorí pé lọ́kàn rẹ̀ a máa pọ́n ara rẹ̀, pé kò sí ẹni tí ó lè rí ẹ̀ṣẹ̀ òun, ká tó wá sọ pé yóo dá òun lẹ́bi.

3 Ọ̀rọ̀ ìkà ati ẹ̀tàn ni ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀. Ó ti dáwọ́ ire ṣíṣe dúró; kò sì hu ìwà ọlọ́gbọ́n mọ́.

4 A máa pète ìkà lórí ibùsùn rẹ̀; a máa rin ọ̀nà tí kò tọ́; kò sì kórìíra ibi.

5 OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ga kan ọ̀run; òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

6 Òtítọ́ rẹ dàbí òkè ńlá; ìdájọ́ rẹ sì jìn bí ibú omi. OLUWA, àtènìyàn, àtẹranko ni ò ń gbàlà.

7 Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ níye lórí pupọ, Ọlọrun! Àwọn ọmọ eniyan a máa sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

8 Wọ́n ń rí oúnjẹ jẹ ní àjẹyó ní ilé rẹ; nǹkan mímu tí ń ṣàn bí odò, ni o sì ń fún wọn mu.

9 Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà; ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.

10 Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ han àwọn tí ó mọ̀ ọ́, sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.

11 Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi, má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.

12 Ẹ wo àwọn aṣebi níbi tí wọ́n ṣubú sí; wọ́n dà wólẹ̀, wọn kò sì le dìde.

37

1 Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí àwọn eniyan burúkú; má sì jowú àwọn aṣebi;

2 nítorí pé kíákíá ni wọn yóo gbẹ bí i koríko; wọn óo sì rọ bí ewé.

3 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA; kí o sì máa ṣe rere. Máa gbe ilẹ̀ náà; ewu kò sì ní wu ọ́.

4 Jẹ́ kí inú rẹ máa dùn ninu OLUWA; yóo sì fún ọ ní ohun tí ọkàn rẹ ń fẹ́.

5 Fi ọ̀nà rẹ lé OLUWA lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé e, yóo sì ṣe ohun tí ó yẹ.

6 Yóo mú kí ìdáláre rẹ tàn bí ìmọ́lẹ̀; ẹ̀tọ́ rẹ yóo sì hàn kedere bí ọ̀sán gangan.

7 Dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú OLUWA; fi sùúrù gbẹ́kẹ̀lé e. Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí ẹni tí nǹkan ń dára fún; tabi nítorí ẹni tí ń gbèrò ibi, tí ó sì ń ṣe é.

8 Yẹra fún ibinu; sì yàgò fún ìrúnú. Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná; ibi ni àyọrísí rẹ̀.

9 Nítorí pé a óo pa àwọn eniyan burúkú run; ṣugbọn àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA ni yóo jogún ilẹ̀ náà.

10 Ẹ fún eniyan burúkú ní ìgbà díẹ̀ sí i, yóo pòórá; ẹ̀ báà wá a títí ní ààyè rẹ̀, kò ní sí níbẹ̀.

11 Ṣugbọn àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ ni yóo jogún ilẹ̀ náà: wọn óo máa gbádùn ara wọn; wọn óo sì ní alaafia lọpọlọpọ.

12 Eniyan burúkú dìtẹ̀ mọ́ olódodo; ó sì ń wò ó bíi kíkú bíi yíyè.

13 Ṣugbọn OLUWA ń fi eniyan burúkú rẹ́rìn-ín, nítorí ó mọ̀ pé ọjọ́ ìparun rẹ̀ ń bọ̀.

14 Àwọn eniyan burúkú fa idà yọ, wọ́n sì kẹ́ ọfà wọn láti gba ẹ̀mí talaka ati aláìní, láti pa àwọn tí ń rìn lọ́nà ẹ̀tọ́.

15 Ṣugbọn idà wọn ni o óo fi pa wọ́n, ọrun wọn yóo sì dá.

16 Nǹkan díẹ̀ tí olódodo ní dára ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ àwọn eniyan burúkú.

17 Nítorí OLUWA yóo ṣẹ́ apá eniyan burúkú, ṣugbọn yóo gbé olódodo ró.

18 OLUWA a máa tọ́jú àwọn aláìlẹ́bi; ilẹ̀ ìní wọn yóo jẹ́ tiwọn títí lae.

19 Ojú kò ní tì wọ́n nígbà tí àjálù bá dé; bí ìyàn tilẹ̀ mú, wọn óo jẹ, wọn óo yó.

20 Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú yóo ṣègbé; àwọn ọ̀tá OLUWA yóo pòórá bí ẹwà ewéko wọn óo parẹ́ bí èéfín tí í parẹ́.

21 Bí eniyan burúkú bá yá owó, kò ní san; ṣugbọn ẹni rere ní ojú àánú, ó sì lawọ́.

22 Nítorí pé àwọn tí Ọlọrun bá bukun ni yóo jogún ilẹ̀ náà, ṣugbọn àwọn tí ó bá fi gégùn-ún yóo parun.

23 OLUWA níí darí ìgbésẹ̀ ẹni; a sì máa fi ẹsẹ̀ ẹni tí inú rẹ̀ bá dùn sí múlẹ̀.

24 Bí ó tilẹ̀ ṣubú, kò ní lulẹ̀ lógèdèǹgbé, nítorí OLUWA yóo gbé e ró.

25 Mo ti jẹ́ ọmọde rí; mo sì ti dàgbà: n kò tíì ri kí á kọ olódodo sílẹ̀, tabi kí ọmọ rẹ̀ máa tọrọ jẹ.

26 Olódodo ní ojú àánú, a sì máa yáni ní nǹkan, ayọ̀ ń bẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27 Ẹ yẹra fún ibi; ẹ sì máa ṣe rere; kí ẹ lè wà ní ààyè yín títí lae.

28 Nítorí OLUWA fẹ́ràn ẹ̀tọ́; kò ní kọ àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sílẹ̀. Yóo máa ṣọ́ wọn títí lae, ṣugbọn a óo pa àwọn ọmọ eniyan burúkú run.

29 Àwọn ẹni rere ni yóo jogún ilẹ̀ náà; wọn óo sì máa gbé orí rẹ̀ títí lae.

30 Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n níí máa jáde lẹ́nu ẹni rere, a sì máa sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́.

31 Òfin Ọlọrun rẹ̀ wà ní ọkàn rẹ̀; ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í yà kúrò níbẹ̀.

32 Eniyan burúkú ń ṣọ́ olódodo, ó ń wá ọ̀nà ati pa á.

33 OLUWA kò ní fi olódodo lé e lọ́wọ́, tabi kí ó jẹ́ kí á dá olódodo lẹ́bi ní ilé ẹjọ́.

34 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, sì máa tọ ọ̀nà rẹ̀, yóo gbé ọ ga, kí o lè jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá pa àwọn eniyan burúkú run, o óo fojú rẹ rí i.

35 Mo ti rí eniyan burúkú tí ń halẹ̀ mọ́ni, tí ó ga bí igi kedari ti Lẹbanoni.

36 Ṣugbọn nígbà tí mo tún gba ibẹ̀ kọjá, mo wò ó, kò sí níbẹ̀ mọ́; mo wá a, ṣugbọn n kò rí i.

37 Ṣe akiyesi ẹni pípé; sì wo olódodo dáradára, nítorí pé ìgbẹ̀yìn ẹni tí ń wá alaafia yóo dára.

38 Ṣugbọn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóo parun patapata, a óo sì run ọmọ àwọn eniyan burúkú.

39 Ọ̀dọ̀ OLUWA ni ìgbàlà àwọn olódodo ti ń wá; òun ni alátìlẹ́yìn wọn ní àkókò ìṣòro.

40 OLUWA a máa ràn wọ́n lọ́wọ́, a sì máa gbà wọ́n; a máa gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú, a sì máa gbà wọ́n là, nítorí pé òun ni wọ́n sá di.

38

1 OLUWA, má fi ibinu bá mi wí! Má sì fi ìrúnú jẹ mí níyà!

2 Nítorí pé ọfà rẹ ti wọ̀ mí lára, ọwọ́ rẹ sì ti bà mí.

3 Kò sí ibìkan tí ó gbádùn ní gbogbo ara mi nítorí ibinu rẹ; kò sì sí alaafia ninu gbogbo egungun mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi.

4 Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti bò mí lórí mọ́lẹ̀; ó rìn mí mọ́lẹ̀ bí ẹrù ńlá tí ó wúwo jù fún mi.

5 Ọgbẹ́ mi ń kẹ̀, ó sì ń rùn, nítorí ìwà òmùgọ̀ mi,

6 Ìbànújẹ́ dorí mi kodò patapata, mo sì ń ṣọ̀fọ̀ kiri tọ̀sán-tòru.

7 Gbogbo ẹ̀gbẹ́ mi ń gbóná fòò, kò sí ibìkan tí ó gbádùn lára mi.

8 Àárẹ̀ mú mi patapata, gbogbo ara sì wó mi; mò ń kérora nítorí ẹ̀dùn ọkàn mi.

9 OLUWA, gbogbo ìfẹ́ ọkàn mi ni o mọ̀, ìmí ẹ̀dùn mi kò sì pamọ́ fún ọ.

10 Àyà mi ń lù pì pì pì, ó rẹ̀ mí láti inú wá; ojú mi sì ti di bàìbàì.

11 Àwọn ọ̀rẹ́ ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi takété sí mi nítorí àrùn mi, àwọn ẹbí mi sì dúró lókèèrè réré.

12 Àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí mi dẹ tàkúté sílẹ̀ dè mí, àwọn tí ń wá ìpalára mi ń sọ̀rọ̀ ìparun mi, wọ́n sì ń pète àrékérekè tọ̀sán-tòru.

13 Ṣugbọn mo ṣe bí adití, n kò gbọ́, mo dàbí odi tí kò le sọ̀rọ̀.

14 Àní, mo dàbí ẹni tí kò gbọ́rọ̀, tí kò sì ní àwíjàre kan lẹ́nu.

15 Ṣugbọn, OLUWA, ìwọ ni mò ń dúró dè; OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni o óo dá mi lóhùn.

16 Nítorí tí mò ń gbadura pé, kí àwọn tí ń pẹ̀gàn mi má yọ̀ mí nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yẹ̀.

17 Nítorí pé mo ti fẹ́rẹ̀ ṣubú, mo sì wà ninu ìrora nígbà gbogbo.

18 Mo jẹ́wọ́ àṣìṣe mi, mo sì káàánú fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.

19 Àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí lágbára, àwọn tí ó kórìíra mi láìtọ́ sì pọ̀.

20 Àwọn tí ń fi ibi san oore fún mi ní ń gbógun tì mí, nítorí pé rere ni mò ń ṣe.

21 OLUWA, má kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọrun mi, má jìnnà sí mi.

22 Yára wá ràn mí lọ́wọ́, OLUWA, ìgbàlà mi.

39

1 Mo ní, “Èmi óo máa ṣọ́ra, kí n má baà fi ahọ́n mi dẹ́ṣẹ̀; n óo kó ẹnu mi ní ìjánu, níwọ̀n ìgbà tí àwọn eniyan burúkú bá wà nítòsí.”

2 Mo dákẹ́, n ò sọ nǹkankan; n ò tilẹ̀ dá sí ọ̀rọ̀ rere pàápàá; sibẹ ìpọ́njú mi ń pọ̀ sí i

3 ìdààmú dé bá ọkàn mi. Bí mo ti ń ronú, ọkàn mi dàrú; mo bá sọ̀rọ̀ jáde, mo ní:

4 “OLUWA, jẹ́ kí n mọ òpin ayé mi, ati ìwọ̀nba ọjọ́ ayé mi, kí n lè mọ̀ pé ayé mi ń sáré kọjá lọ.”

5 Wò ó, o ti ṣe ọjọ́ mi ní ìwọ̀n ìbú àtẹ́lẹwọ́ mélòó kan, ọjọ́ ayé mi kò sì tó nǹkankan ní ojú rẹ; dájúdájú, ọmọ eniyan dàbí afẹ́fẹ́ lásán.

6 Dájúdájú, eniyan ń káàkiri bí òjìji, asán sì ni gbogbo làálàá rẹ̀; eniyan a máa kó ọrọ̀ jọ ṣá, láìmọ ẹni tí yóo kó o lọ.

7 Wàyí ò, OLUWA, kí ló kù tí mo gbójú lé? Ìwọ ni mo fẹ̀yìn tì.

8 Gbà mí ninu gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ìrékọjá mi; má sọ mí di ẹni ẹ̀gàn lójú àwọn òmùgọ̀.

9 Mo dákẹ́, n kò ya ẹnu mi; nítorí pé ìwọ ni o ṣe é.

10 Dáwọ́ ẹgba rẹ dúró lára mi, mo ti fẹ́rẹ̀ kú nítorí ìyà tí o fi ń jẹ mí.

11 Nígbà tí o bá jẹ eniyan níyà pẹlu ìbáwí nítorí ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ á ba ohun tí ó ṣọ̀wọ́n fún un jẹ́ bíi kòkòrò aṣọ. Dájúdájú, afẹ́fẹ́ lásán ni eniyan.

12 “OLUWA, gbọ́ adura mi, tẹ́tí sí igbe mi, má dágunlá sí ẹkún mi, nítorí pé àlejò rẹ, tí ń rékọjá lọ ni mo jẹ́; àjèjì sì ni mí, bíi gbogbo àwọn baba mi.

13 Mú ojú ìbáwí kúrò lára mi, kí inú mi lè dùn kí n tó kọjá lọ; àní, kí n tó ṣe aláìsí.”

40

1 Sùúrù ni mo fi dúró de OLUWA, ó dẹ etí sí mi, ó sì gbọ́ igbe mi.

2 Ó fà mí jáde láti inú ọ̀gbun ìparun, láti inú kòtò tí ó kún fún ẹrọ̀fọ̀; ó gbé mi kalẹ̀ lórí àpáta, ó sì fi ẹsẹ̀ mi tẹlẹ̀.

3 Ó fi orin titun sí mi lẹ́nu, àní, orin ìyìn sí Ọlọrun wa. Ọ̀pọ̀ yóo rí i, ẹ̀rù óo bà wọ́n, wọn óo sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

4 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni náà, tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé OLUWA, tí kò bá àwọn onigbeeraga rìn, àwọn tí wọn ti ṣìnà lọ sọ́dọ̀ àwọn oriṣa.

5 OLUWA, Ọlọrun mi, o ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu fún wa, o sì ti ro ọ̀pọ̀ èrò rere kàn wá. Kò sí ẹni tí a lè fi wé ọ; bí mo bá ní kí n máa polongo ohun tí o ṣe, kí n máa ròyìn wọn, wọ́n ju ohun tí eniyan lè kà lọ.

6 O ò fẹ́ ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni o ò fẹ́ ọrẹ, ṣugbọn o là mí ní etí; o ò bèèrè ẹbọ sísun tabi ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.

7 Nígbà náà ni mo wí pé, “Wò ó, mo dé; a ti kọ nípa mi sinu ìwé pé:

8 mo gbádùn láti máa ṣe ìfẹ́ rẹ, Ọlọrun mi; mo sì ń pa òfin rẹ mọ́ ninu ọkàn mi.”

9 Mo ti ròyìn òdodo ninu àwùjọ ńlá. Wò ó, OLUWA n kò pa ẹnu mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀.

10 Èmi kò fi ìròyìn ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà rẹ pamọ́. Mo sọ̀rọ̀ òtítọ́ ati ìgbàlà rẹ; n kò dákẹ́ lẹ́nu nípa òtítọ́ ati ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, ninu àwùjọ ńlá.

11 Má dáwọ́ àánú rẹ dúró lórí mi, OLUWA, sì jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ rẹ máa pa mí mọ́.

12 Nítorí pé àìmọye ìdààmú ló yí mi ká, ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi ti tẹ̀ mí, tóbẹ́ẹ̀ tí n kò ríran. Wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, ọkàn mi ti dàrú.

13 OLUWA, dákun gbà mi; yára, OLUWA, ràn mí lọ́wọ́.

14 Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ gba ẹ̀mí mi, kí ìdàrúdàpọ̀ bá gbogbo wọn patapata, jẹ́ kí á lé àwọn tí ń wá ìpalára mi pada sẹ́yìn, kí wọ́n sì tẹ́.

15 Jẹ́ kí jìnnìjìnnì bò wọ́n, kí wọ́n sì gba èrè ìtìjú, àní, àwọn tí ń ṣe jàgínní mi.

16 Kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ máa yọ̀, kí inú wọn sì máa dùn nítorí rẹ; kí àwọn tí ó fẹ́ràn ìgbàlà rẹ máa wí nígbà gbogbo pé, “OLUWA tóbi!”

17 Ní tèmi, olùpọ́njú ati aláìní ni mí; ṣugbọn Oluwa kò gbàgbé mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ ati olùgbàlà mi, má pẹ́, Ọlọrun mi.

41

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń ro ti àwọn aláìní: OLUWA yóo gbà á ní ọjọ́ ìpọ́njú.

2 OLUWA yóo máa ṣọ́ ọ, yóo sì dá a sí. Yóo ní ayọ̀ ní ilẹ̀ náà; OLUWA kò ní fi í lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

3 Nígbà tí ó bá wà ní ìdùbúlẹ̀ àìsàn, OLUWA yóo fún un lókun; ní àkókò àìlera OLUWA yóo wo gbogbo àrùn rẹ̀ sàn.

4 Mo ní, “OLUWA, ṣàánú mi kí o sì wò mí sàn; mo ti ṣẹ̀ ọ́.”

5 Àwọn ọ̀tá mi ń ro ibi sí mi, wọ́n ń wí pé, “Nígbà wo ni yóo kú, tí orúkọ rẹ̀ yóo parẹ́?”

6 Tí ọ̀kan bá wá bẹ̀ mí wò, ọ̀rọ̀ tí kò lórí, tí kò nídìí ni yóo máa sọ; bẹ́ẹ̀ ni ninu ọkàn rẹ̀, èrò ibi ni yóo máa gbà. Nígbà tí ó bá jáde, yóo máa rò mí kiri.

7 Gbogbo àwọn tí ó kórìíra mi jọ ń sọ̀rọ̀ wújẹ́wújẹ́ nípa mi; ohun tó burú jùlọ ni wọ́n ń rò sí mi.

8 Wọ́n ń wí pé, “Àìsàn burúkú ti gbé e dálẹ̀; kò ní dìde mọ́ níbi tí ó dùbúlẹ̀ sí.”

9 Àní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi tí mo gbẹ́kẹ̀lé, tí ó ń jẹun nílé mi, ó ti kẹ̀yìn sí mí.

10 Ṣugbọn, OLUWA, ṣàánú mi; gbé mi dìde, kí n lè san ẹ̀san fún un.

11 Kí n lè mọ̀ pé o fẹ́ràn mi, nígbà tí ọ̀tá kò bá borí mi.

12 O ti gbé mi ró nítorí ìwà pípé mi, o sì fi ẹsẹ̀ mi múlẹ̀ níwájú rẹ títí lae.

13 Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun Israẹli, lae ati laelae. Amin! Amin!

42

1 Bí ọkàn àgbọ̀nrín tií máa fà sí odò tí omi rẹ̀ tutù, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń fà sí ọ, Ọlọrun.

2 Òùngbẹ Ọlọrun ń gbẹ ọkàn mi, àní, òùngbẹ Ọlọrun alààyè. Nígbà wo ni n óo lọ, tí n óo tún bá Ọlọrun pàdé?

3 Omijé ni mo fi ń ṣe oúnjẹ jẹ tọ̀sán-tòru, nígbà tí wọn ń bi mí lemọ́lemọ́ pé, “Níbo ni Ọlọrun rẹ wà?”

4 Àwọn nǹkan wọnyi ni mò ń ranti, bí mo ti ń tú ẹ̀dùn ọkàn mi jáde: bí mo ṣe máa ń bá ogunlọ́gọ̀ eniyan rìn, tí mò ń ṣáájú wọn, bí a bá ti ń rìn lọ́wọ̀ọ̀wọ́ lọ sí ilé Ọlọrun; pẹlu ìhó ayọ̀ ati orin ọpẹ́, láàrin ogunlọ́gọ̀ eniyan tí ń ṣe àjọ̀dún.

5 Ìwọ ọkàn mi, kí ló dé tí o fi rẹ̀wẹ̀sì? Kí ló dé tí ara rẹ kò fi balẹ̀ ninu mi? Gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ọlọrun, nítorí pé n óo tún yìn ín, olùrànlọ́wọ́ mi ati Ọlọrun mi.

6 Ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi, nítorí náà mo ranti rẹ láti òkè Herimoni, ati láti òkè Misari, wá sí agbègbè odò Jọdani,

7 ìbànújẹ́ ń já lura wọn, ìdààmú sì ń dà gììrì, wọ́n bò mí mọ́lẹ̀ bí ìgbì omi òkun.

8 Ní ọ̀sán, OLUWA fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn, ní òru, orin rẹ̀ gba ẹnu mi, àní, adura sí Ọlọrun ìyè mi.

9 Mo bi Ọlọrun, àpáta mi pé, “Kí ló dé tí o fi gbàgbé mi? Kí ló dé tí mò ń ṣọ̀fọ̀ kiri nítorí ìnilára ọ̀tá?”

10 Bí ọgbẹ́ aṣekúpani ni ẹ̀gàn àwọn ọ̀tá mi rí lára mi, nígbà tí wọn ń bi mí lemọ́lemọ́ pé, “Níbo ni Ọlọrun rẹ wà?”

11 Ìwọ ọkàn mi, kí ló dé tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì? Kí ló dé tí ara rẹ kò fi balẹ̀ ninu mi? Gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ọlọrun; nítorí pé n óo tún yìn ín, olùrànlọ́wọ́ mi ati Ọlọrun mi.

43

1 Dá mi láre, Ọlọrun, kí o sì gbèjà mi, lọ́dọ̀ àwọn tí kò mọ̀ Ọ́; gbà mí lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́tàn ati alaiṣootọ.

2 Nítorí ìwọ ni Ọlọrun tí mo sá di. Kí ló dé tí o fi ta mí nù? Kí ló dé tí mo fi ń ṣọ̀fọ̀ kiri nítorí ìnilára ọ̀tá?

3 Rán ìmọ́lẹ̀ rẹ ati òtítọ́ rẹ jáde, jẹ́ kí wọ́n máa tọ́ mi sọ́nà; jẹ́ kí wọ́n mú mi wá sí orí òkè mímọ́ rẹ, ati ibùgbé rẹ.

4 Nígbà náà ni n óo lọ sí ibi pẹpẹ Ọlọrun, àní, sọ́dọ̀ Ọlọrun, ayọ̀ ńlá mi. Èmi óo sì yìn ọ́ pẹlu hapu, Ọlọrun, Ọlọrun mi.

5 Ìwọ ọkàn mi, kí ló dé tí o fi rẹ̀wẹ̀sì? Kí ló dé tí ara rẹ kò fi balẹ̀ ninu mi? Gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ọlọrun; nítorí pé n óo tún yìn ín, olùrànlọ́wọ́ mi ati Ọlọrun mi.

44

1 Ọlọrun, a ti fi etí wa gbọ́, àwọn baba wa sì ti sọ fún wa, nípa àwọn ohun tí o ṣe nígbà ayé wọn, àní, ní ayé àtijọ́:

2 Ìwọ ni o fi ọwọ́ ara rẹ lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde fún wọn, tí o sì fi ẹsẹ̀ àwọn baba wa múlẹ̀; o fi ìyà jẹ àwọn orílẹ̀-èdè náà, o sì jẹ́ kí ó dára fún àwọn baba wa.

3 Nítorí pé kì í ṣe idà wọn ni wọ́n fi gba ilẹ̀ náà, kì í ṣe agbára wọn ni wọ́n fi ṣẹgun; agbára rẹ ni; àní, agbára ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ati ojurere rẹ; nítorí pé inú rẹ dùn sí wọn.

4 Ìwọ ni Ọba mi ati Ọlọrun mi; ìwọ ni o fi àṣẹ sí i pé kí Jakọbu ó ṣẹgun.

5 Nípa agbára rẹ ni a fi bi àwọn ọ̀tá wa sẹ́yìn, orúkọ rẹ ni a fi tẹ àwọn tí ó gbógun tì wá mọ́lẹ̀.

6 Nítorí pé kì í ṣe ọrun mi ni mo gbẹ́kẹ̀lé; idà mi kò sì le gbà mí.

7 Ṣugbọn ìwọ ni o gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, o sì dójú ti àwọn tí ó kórìíra wa.

8 Ìwọ Ọlọrun ni a fi ń yangàn nígbà gbogbo; a óo sì máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ títí lae.

9 Sibẹ, o ti ta wá nù o sì ti rẹ̀ wá sílẹ̀, o ò sì bá àwọn ọmọ ogun wa jáde lọ sójú ogun mọ́.

10 O ti mú kí á sá fún àwọn ọ̀tá wa lójú ogun; àwọn tí ó kórìíra wa sì fi ẹrù wa ṣe ìkógun.

11 O ti ṣe wá bí aguntan lọ́wọ́ alápatà, o sì ti fọ́n wa káàkiri àwọn orílẹ̀-èdè.

12 O ti ta àwọn eniyan rẹ lọ́pọ̀, o ò sì jẹ èrè kankan lórí wọn.

13 O ti sọ wá di ẹni ẹ̀gàn lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wa; a di ẹni ẹ̀sín ati ẹni yẹ̀yẹ́ lọ́dọ̀ àwọn tí ó yí wa ká.

14 O sọ wá di ẹni àmúpòwe láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, ati ẹni yẹ̀yẹ́ láàrin gbogbo ayé.

15 Àbùkù mi wà lára mi tọ̀sán-tòru, ìtìjú sì ti bò mí.

16 Ọ̀rọ̀ àwọn apẹ̀gàn ati apeni-níjà ṣẹ mọ́ mi lára, lójú àwọn ọ̀tá mi ati àwọn tí ó fẹ́ gbẹ̀san.

17 Gbogbo nǹkan yìí ló ṣẹlẹ̀ sí wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò gbàgbé rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò yẹ majẹmu rẹ.

18 Ọkàn wa kò pada lẹ́yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò yẹsẹ̀ kúrò ninu ìlànà rẹ,

19 sibẹ o fọ́ wa túútúú fún ìjẹ àwọn ẹranko, o sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20 Bí ó bá jẹ́ pé a gbàgbé orúkọ Ọlọrun wa, tabi tí a bá bọ oriṣa,

21 ṣebí Ọlọrun ìbá ti mọ̀? Nítorí òun ni olùmọ̀ràn ọkàn.

22 Ṣugbọn nítorí tìrẹ ni wọ́n fi ń pa wá tọ̀sán-tòru, tí a kà wá sí aguntan lọ́wọ́ alápatà.

23 Para dà, OLUWA, kí ló dé tí o fi ń sùn? Jí gìrì! Má ta wá nù títí lae.

24 Kí ló dé tí o fi ń fi ojú pamọ́? Kí ló dé tí o fi gbàgbé ìpọ́njú ati ìnira wa?

25 Nítorí pé àwọn ọ̀tá ti tẹ̀ wá mọ́lẹ̀; àyà wa sì lẹ̀ mọ́lẹ̀ típẹ́típẹ́.

26 Gbéra nílẹ̀, kí o ràn wá lọ́wọ́! Gbà wá sílẹ̀ nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

45

1 Èrò rere kan ń gbé mi lọ́kàn, mò ń kọ orin mi fún ọba ahọ́n mi dàbí gègé akọ̀wé tó mọṣẹ́.

2 Ìwọ ni o dára jùlọ láàrin àwọn ọkunrin; ọ̀rọ̀ dùn lẹ́nu rẹ, nítorí náà Ọlọrun ti bukun ọ títí ayé.

3 Sán idà rẹ mọ́ ìdí, ìwọ alágbára, ninu ògo ati ọlá ńlá rẹ.

4 Máa gun ẹṣin ìṣẹ́gun lọ ninu ọlá ńlá rẹ, máa jà fún òtítọ́ ati ẹ̀tọ́, kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ fún ọ ní ìṣẹ́gun ńlá.

5 Àwọn ọfà rẹ mú, wọ́n gún àwọn ọ̀tá ọba lọ́kàn, àwọn eniyan ń wó lulẹ̀ níwájú rẹ.

6 Ìjọba tí Ọlọrun fún ọ wà lae ati laelae. Ọ̀pá àṣẹ rẹ, ọ̀pá àṣẹ ẹ̀tọ́ ni.

7 O fẹ́ràn òdodo, o sì kórìíra ìwà ìkà nítorí náà ni Ọlọrun, àní Ọlọrun rẹ, ṣe fi àmì òróró yàn ọ́. Àmì òróró ayọ̀ ni ó fi gbé ọ ga ju àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ lọ.

8 Aṣọ rẹ kún fún òórùn oríṣìíríṣìí turari, láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ ni wọ́n tí ń fi ohun èlò ìkọrin olókùn dá ọ lára yá.

9 Àwọn ọmọ ọba wà lára àwọn obinrin inú àgbàlá rẹ, ayaba dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ó fi ojúlówó wúrà ṣe ọ̀ṣọ́ sára.

10 Gbọ́, ìwọ ọmọbinrin, ronú kí o sì tẹ́tí sílẹ̀, gbàgbé àwọn eniyan rẹ ati ilé baba rẹ;

11 ẹwà rẹ yóo sì mú ọ wu ọba; òun ni oluwa rẹ, nítorí náà bu ọlá fún un.

12 Àwọn ará Tire yóo máa fi ẹ̀bùn wá ojurere rẹ, àní, àwọn eniyan tí wọ́n ní ọrọ̀ jùlọ.

13 Yóo máa wá ojurere rẹ, pẹlu oríṣìíríṣìí ọrọ̀. Ọmọ ọbabinrin fi aṣọ wúrà ṣọ̀ṣọ́ jìngbìnnì ninu yàrá rẹ̀,

14 ó wọ aṣọ aláràbarà, a mú un lọ sọ́dọ̀ ọba, pẹlu àwọn wundia ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ tí wọn ń sìn ín lọ.

15 Pẹlu ayọ̀ ati inú dídùn ni a fi ń mú wọn lọ, bí wọ́n ṣe ń wọ ààfin ọba.

16 Àwọn ọmọkunrin rẹ ni yóo rọ́pò àwọn baba rẹ; o óo fi wọ́n jọba káàkiri gbogbo ayé.

17 N óo mú kí á máa ki oríkì rẹ láti ìran dé ìran; nítorí náà àwọn eniyan yóo máa yìn ọ́ lae ati laelae.

46

1 Ọlọrun ni ààbò ati agbára wa, olùrànlọ́wọ́ tí ó wà nítòsí nígbà gbogbo, ní ìgbà ìpọ́njú.

2 Nítorí náà ẹ̀rù kò ní bà wá bí ayé tilẹ̀ ṣídìí, bí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ṣípò pada, tí wọ́n bọ́ sinu òkun;

3 bí omi òkun tilẹ̀ ń hó, tí ó sì ń ru, tí àwọn òkè ńlá sì ń mì tìtì nítorí agbára ríru rẹ̀.

4 Odò kan wà tí omi rẹ̀ ń mú inú ìlú Ọlọrun dùn, ìlú yìí ni ibùgbé mímọ́ Ọ̀gá Ògo.

5 Ọlọrun wà láàrin rẹ̀, kò ní tú bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣí kúrò; Ọlọrun yóo ràn án lọ́wọ́ ní òwúrọ̀ kutukutu.

6 Inú àwọn orílẹ̀-èdè ń ru, àwọn ìjọba ayé ń gbọ̀n; OLUWA fọhùn, ayé sì yọ́.

7 OLUWA àwọn ọmọ ogun wà pẹlu wa; Ọlọrun Jakọbu ni ààbò wa.

8 Ẹ wá wo iṣẹ́ OLUWA, irú iṣẹ́ ribiribi tí ó ṣe láyé.

9 Ó dáwọ́ ogun dúró ní gbogbo ayé, ó ṣẹ́ ọrun, ó rún ọ̀kọ̀, ó dáná sun kẹ̀kẹ́ ogun.

10 “Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ni Ọlọrun. A gbé mi ga láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, a gbé mi ga ní ayé.”

11 OLUWA àwọn ọmọ ogun wà pẹlu wa, Ọlọrun Jakọbu ni ààbò wa.

47

1 Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; ẹ kọ orin ayọ̀, ẹ hó sí Ọlọrun.

2 Nítorí pé ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ni OLUWA, Ọ̀gá Ògo, Ọba ńlá lórí gbogbo ayé.

3 Ó tẹ àwọn orílẹ̀-èdè lórí ba fún wa, ó sì sọ àwọn orílẹ̀-èdè di àtẹ̀mọ́lẹ̀ fún wa.

4 Òun ni ó yan ilẹ̀ ìní wa fún wa, èyí tí àwọn ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀, fi ń yangàn.

5 A ti gbé Ọlọrun ga pẹlu ìhó ayọ̀, a ti gbé OLUWA ga pẹlu ìró fèrè.

6 Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọlọrun, ẹ kọ orin ìyìn; Ẹ kọ orin ìyìn sí Ọba wa, ẹ kọ orin ìyìn!

7 Nítorí Ọlọrun ni Ọba gbogbo ayé; Ẹ fi gbogbo ohun èlò ìkọrin kọ orin ìyìn!

8 Ọlọrun jọba lórí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè; Ó gúnwà lórí ìtẹ́ mímọ́ rẹ̀.

9 Àwọn ìjòyè orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ pẹlu àwọn eniyan Ọlọrun Abrahamu. Ọlọrun ni aláṣẹ gbogbo ayé; òun ni ọlọ́lá jùlọ!

48

1 OLUWA tóbi, ó sì yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọ ní ìlú Ọlọrun wa.

2 Òkè mímọ́ rẹ̀, tí ó ga, tí ó sì lẹ́wà, ni ayọ̀ gbogbo ayé. Òkè Sioni, ní àríwá, lọ́nà jíjìn réré, ìlú ọba ńlá.

3 Ninu ilé ìṣọ́ ìlú náà, Ọlọrun ti fi ara rẹ̀ hàn bí ibi ìsádi.

4 Wò ó! Àwọn ọba kó ara wọn jọ; wọ́n jùmọ̀ gbógun tì í.

5 Nígbà tí wọ́n fojú kàn án, ẹnu yà wọ́n, ìpayà mú wọn, wọ́n sì sá;

6 ìwárìrì mú wọn níbẹ̀; ìrora sì bá wọn bí obinrin tí ń rọbí.

7 Ó fọ́ wọn bí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn tií fọ́ ọkọ̀ Taṣiṣi.

8 Bí a ti gbọ́, bẹ́ẹ̀ gan-an ni ó rí, ní ìlú OLUWA àwọn ọmọ ogun, ní ìlú Ọlọrun wa: Ọlọrun fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

9 Ninu tẹmpili rẹ, Ọlọrun, à ń ṣe àṣàrò lórí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

10 Ọlọrun, ìyìn rẹ tàn ká, bí orúkọ rẹ ṣe tàn dé òpin ayé, iṣẹ́ rere kún ọwọ́ rẹ.

11 Jẹ́ kí inú òkè Sioni kí ó dùn, kí gbogbo Juda sì máa yọ̀ nítorí ìdájọ́ rẹ.

12 Ẹ rìn yí Sioni po; ẹ yí i ká; ẹ ka àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀;

13 ẹ ṣàkíyèsí odi rẹ̀; ẹ wọ inú gbogbo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lọ, kí ẹ lè ròyìn fún ìran tí ń bọ̀

14 pe: “Ọlọrun yìí ni Ọlọrun wa, lae ati laelae. Òun ni yóo máa ṣe amọ̀nà wa títí lae.”

49

1 Ẹ gbọ́, gbogbo orílẹ̀-èdè! Ẹ dẹtí sílẹ̀, gbogbo aráyé,

2 ati mẹ̀kúnnù àtọlọ́lá, àtolówó ati talaka!

3 Ẹnu mi yóo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n; àṣàrò ọkàn mi yóo sì jẹ́ ti òye.

4 N óo tẹ́tí sílẹ̀ sí òwe; n óo sì fi hapu túmọ̀ rẹ̀.

5 Kí ló dé tí n óo fi bẹ̀rù ní àkókò ìyọnu, nígbà tí iṣẹ́ ibi àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi bá yí mi ká,

6 àwọn tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọ́n sì ń yangàn nítorí wọ́n ní ọrọ̀ pupọ?

7 Dájúdájú, kò sí ẹni tí ó le ra ara rẹ̀ pada, tabi tí ó lè san owó ìràpadà ẹ̀mí rẹ̀ fún Ọlọrun;

8 nítorí pé ẹ̀mí eniyan níye lórí pupọ. Kò sí iye tí eniyan ní tí ó le kájú rẹ̀,

9 tí eniyan lè máa fi wà láàyè títí lae, kí ó má fojú ba ikú.

10 Yóo rí i pé ikú a máa pa ọlọ́gbọ́n, òmùgọ̀ ati òpè a sì máa rọ̀run; wọn a sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.

11 Ibojì wọn ni ilé wọn títí lae, ibẹ̀ ni ibùgbé wọn títí ayérayé, wọn ìbáà tilẹ̀ ní ilẹ̀ ti ara wọn.

12 Eniyan kò lè máa gbé ninu ọlá rẹ̀ títí ayé, bí ẹranko tíí kú, ni òun náà óo kú.

13 Ìpín àwọn tí ó ní igbẹkẹle asán nìyí, òun sì ni èrè àwọn tí ọrọ̀ wọn tẹ́ lọ́rùn.

14 Ikú ni ìpín wọn bí àgùntàn lásánlàsàn, ikú ni yóo máa ṣe olùṣọ́ wọn; ibojì ni wọ́n sì ń lọ tààrà. Wọn yóo jẹrà, ìrísí wọn óo sì parẹ́, Àwọn olódodo yóo jọba lórí wọn ní òwúrọ̀, ibojì ni yóo sì máa jẹ́ ilé wọn.

15 Ṣugbọn Ọlọrun yóo ra ẹ̀mí mi pada lọ́wọ́ ikú nítorí pé yóo gbà mí.

16 Má ba ara jẹ́ bí ẹnìkan bá di olówó, tí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i.

17 Nítorí pé ní ọjọ́ tí ó bá kú, kò ní mú ohunkohun lọ́wọ́ lọ; dúkìá rẹ̀ kò sì ní bá a wọ ibojì.

18 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nígbà tí ó wà láàyè, ó rò pé Ọlọrun bukun òun, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé a máa yin eniyan nígbà tí nǹkan bá ń dára fún un,

19 yóo kú bí àwọn baba ńlá rẹ̀ ti kú, kò sì ní fojú kan ìmọ́lẹ̀ mọ́.

20 Eniyan kò lè máa gbé inú ọlá rẹ̀ títí ayé; bí ẹranko tíí kú, ni òun náà óo ku.

50

1 OLUWA, Ọlọrun Alágbára ti sọ̀rọ̀: ó ké sí gbogbo ayé láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.

2 Ọlọrun yọ bí ọjọ́ láti Sioni, ìlú tó dára, tó lẹ́wà.

3 Ọlọrun wa ń bọ̀, kò dákẹ́: iná ajónirun ń jó níwájú rẹ̀; ìjì líle sì ń jà yí i ká.

4 Ó ké sí ọ̀run lókè; ó pe ayé pẹlu láti gbọ́ ìdájọ́ tí yóo ṣe fún àwọn eniyan rẹ̀.

5 Ó ní, “Ẹ kó àwọn olùfọkànsìn mi jọ sọ́dọ̀ mi, àwọn tí wọ́n ti fi ẹbọ bá mi dá majẹmu!”

6 Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀ pé Ọlọrun ni onídàájọ́.

7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan mi, n óo sọ̀rọ̀, Israẹli, n óo takò yín. Èmi ni Ọlọrun, Ọlọrun yín.

8 N kò ba yín wí nítorí ẹbọ rírú; nígbà gbogbo ni ẹ̀ ń rú ẹbọ sísun sí mi.

9 N kò ní gba akọ mààlúù lọ́wọ́ yín, tabi òbúkọ láti agbo ẹran yín.

10 Nítorí èmi ni mo ni gbogbo ẹran inú igbó, tèmi sì ni gbogbo mààlúù tó wà lórí ẹgbẹrun òkè.

11 Gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ni mo mọ̀, tèmi sì ni gbogbo nǹkan tí ń rìn ninu pápá.

12 “Bí ebi bá tilẹ̀ pa mí, ẹ̀yin kọ́ ni n óo sọ fún, nítorí èmi ni mo ni gbogbo ayé ati àwọn nǹkan tí ó wà ninu rẹ̀.

13 Ṣé èmi a máa jẹ ẹran akọ mààlúù? Àbí mà máa mu ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́?

14 Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun, kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.

15 Ẹ ké pè mí ní ọjọ́ ìṣòro; n óo gbà yín, ẹ óo sì yìn mí lógo.”

16 Ṣugbọn Ọlọrun bi àwọn eniyan burúkú pé, “Ẹ̀tọ́ wo ni ẹ níláti máa ka àwọn òfin mi, tabi láti máa mú ẹnu ba ìlànà mi?

17 Nítorí ẹ kórìíra ẹ̀kọ́; ẹ sì ti ta àṣẹ mi nù.

18 Tí ẹ bá rí olè, ẹ̀yin pẹlu rẹ̀ a dọ̀rẹ́; ẹ sì ń bá àwọn panṣaga kẹ́gbẹ́.

19 “Ọ̀rọ̀ ibi dùn lẹ́nu yín pupọ; ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sì yọ̀ létè yín.

20 Ẹ̀ ń jókòó sọ̀rọ̀ arakunrin yín níbi: ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ nípa ọmọ ìyá yín.

21 Gbogbo nǹkan wọnyi ni ẹ ti ṣe tí mo sì dákẹ́; ẹ wá ń rò ninu yín pé, èmi yín rí bákan náà. Ṣugbọn nisinsinyii mò ń ba yín wí, mo sì ń fi ẹ̀sùn kàn yín.

22 “Nítorí náà, ẹ fi èyí lékàn, ẹ̀yin tí ẹ gbàgbé Ọlọrun, kí n má baà fà yín ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kò sì ní sí ẹni tí yóo gbà yín kalẹ̀.

23 Ẹni tí ó bá mu ọpẹ́ wá, tí ó fi rúbọ sí mi, ni ó bu ọlá fún mi; ẹni tí ó bá sì rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ ni èmi Ọlọrun yóo gbà là.”

51

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀; nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ pa ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2 Wẹ̀ mí mọ́ kúrò ninu àìdára mi, kí o sì wẹ̀ mí kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3 Nítorí mo mọ ibi tí mo ti ṣẹ̀, nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi sì wà níwájú mi.

4 Ìwọ nìkan, àní, ìwọ nìkan ṣoṣo ni mo ṣẹ̀, tí mo ṣe ohun tí ó burú lójú rẹ, kí ẹjọ́ rẹ lè tọ́ nígbà tí o bá ń dájọ́, kí ọkàn rẹ lè mọ́ nígbà tí o bá ń ṣe ìdájọ́.

5 Dájúdájú, ninu àìdára ni a bí mi, ninu ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mi sì lóyún mi.

6 O fẹ́ràn òtítọ́ inú; nítorí náà, kọ́ mi lọ́gbọ́n ní kọ́lọ́fín ọkàn mi.

7 Fi ewé hisopu fọ̀ mí, n óo sì mọ́; wẹ̀ mí, n óo sì funfun ju ẹ̀gbọ̀n òwú lọ.

8 Fún mi ní ayọ̀ ati inú dídùn, kí gbogbo egungun mi tí ó ti rún lè máa yọ̀.

9 Mójú kúrò lára ẹ̀ṣẹ̀ mi, kí o sì pa gbogbo àìdára mi rẹ́.

10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọrun, kí o sì fi ẹ̀mí ọ̀tun ati ẹ̀mí ìṣòótọ́ sí mi lọ́kàn.

11 Má ta mí nù kúrò lọ́dọ̀ rẹ, má sì gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12 Dá ayọ̀ ìgbàlà rẹ pada fún mi, kí o sì fi ẹ̀mí àtiṣe ìfẹ́ rẹ gbé mi ró.

13 Nígbà náà ni n óo máa kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ọ̀nà rẹ, àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóo sì máa yipada sí ọ.

14 Gbà mí lọ́wọ́ ẹ̀bi ìpànìyàn, Ọlọrun, ìwọ Ọlọrun, Olùgbàlà mi, n óo sì máa fi orin kéde iṣẹ́ rere rẹ.

15 OLUWA, là mí ní ohùn, n óo sì máa ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ.

16 Bí ó bá jẹ́ pé o fẹ́ ẹbọ ni, ǹ bá mú wá fún ọ; ṣugbọn o ò tilẹ̀ fẹ́ ẹbọ sísun.

17 Ẹbọ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ ìwọ Ọlọrun ni ẹ̀mí ìròbìnújẹ́, ọkàn ìròbìnújẹ́ ati ìrònúpìwàdà ni ìwọ kì yóo gàn.

18 Jẹ́ kí ó dára fún Sioni ninu ìdùnnú rẹ; tún odi Jerusalẹmu mọ.

19 Nígbà náà ni inú rẹ yóo dùn sí ẹbọ tí ó tọ́, ẹbọ sísun, ati ẹbọ tí a sun lódidi; nígbà náà ni a óo fi akọ mààlúù rúbọ lórí pẹpẹ rẹ.

52

1 Ìwọ alágbára, kí ló dé tí o fi ń fọ́nnu, kí ló dé tí ò ń fọ́nnu tọ̀sán-tòru? Ẹni ìtìjú ni ọ́ lójú Ọlọrun.

2 Ò ń pète ìparun; ẹnu rẹ dàbí abẹ tí ó mú, ìwọ alárèékérekè.

3 O fẹ́ràn ibi ju ire lọ, o sì fẹ́ràn irọ́ ju òtítọ́ lọ.

4 O fẹ́ràn gbogbo ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́, Ìwọ ẹlẹ́tàn!

5 Nítòótọ́ Ọlọrun óo bá ọ kanlẹ̀, yóo gbá ọ mú, yóo sì fà ọ́ já kúrò ninu ilé rẹ; yóo fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè.

6 Nígbà tí àwọn olódodo bá rí i, ẹ̀rù óo bà wọ́n, wọn óo fi rẹ́rìn-ín, wọn óo sì wí pé,

7 “Wo ẹni tí ó kọ̀, tí kò fi Ọlọrun ṣe ààbò rẹ̀, ṣugbọn ó gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀, ati jamba tí ó ń ta fún ẹlòmíràn.”

8 Ṣugbọn èmi dàbí igi olifi tútù tí ń dàgbà ninu ilé OLUWA, mo gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọrun tí kì í yẹ̀, lae ati laelae.

9 N óo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ títí lae, nítorí ohun tí o ṣe, n óo máa kéde orúkọ rẹ níwájú àwọn olùfọkànsìn rẹ, nítorí pé ó dára bẹ́ẹ̀.

53

1 Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Kò sí Ọlọrun.” Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni wọ́n ń ṣe, kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.

2 Ọlọrun bojú wo àwọn ọmọ eniyan láti ọ̀run wá, ó ń wò ó bí àwọn kan bá wà tí òye yé, àní, bí àwọn kan bá wà tí ń wá Ọlọrun.

3 Gbogbo wọn ni ó ti yapa; tí wọn sì ti bàjẹ́, kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere, kò sí, bó tilẹ̀ jẹ́ ẹnìkan ṣoṣo.

4 Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni? Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun, àní àwọn tí kì í ké pe Ọlọrun.

5 Ẹ wò wọ́n, bí wọ́n ṣe wà ninu ẹ̀rù ńlá, ẹ̀rù tí kò tíì sí irú rẹ̀ rí! Nítorí Ọlọrun yóo fọ́n egungun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ká; ojú óo tì wọ́n, nítorí Ọlọrun ti kọ̀ wọ́n.

6 Ìbá ti dára tó, kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá! Nígbà tí Ọlọrun bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada, Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

54

1 Fi agbára orúkọ rẹ gbà mí, Ọlọrun, fi ipá rẹ dá mi láre.

2 Gbọ́ adura mi, Ọlọrun; tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

3 Nítorí pé àwọn agbéraga dìde sí mi, àwọn ìkà, aláìláàánú sì ń lépa ẹ̀mí mi; wọn kò bìkítà fún Ọlọrun.

4 Ṣugbọn Ọlọrun ni olùrànlọ́wọ́ mi, OLUWA ni ó gbé ẹ̀mí mi ró.

5 Yóo san ẹ̀san ibi fún àwọn ọ̀tá mi; OLUWA, nítorí òtítọ́ rẹ, pa wọ́n run.

6 N óo rú ẹbọ ọrẹ àtinúwá sí ọ, n óo máa yin orúkọ rẹ, OLUWA, nítorí pé ó dára bẹ́ẹ̀.

7 O ti yọ mí ninu gbogbo ìṣòro mi, mo sì ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi.

55

1 Tẹ́tí sí adura mi, Ọlọrun, má sì fara pamọ́ nígbà tí mo bá ń bẹ̀bẹ̀.

2 Fetí sí mi, kí o sì dá mi lóhùn; ìṣòro ti borí mi.

3 Ìhàlẹ̀ ọ̀tá bà mí ninu jẹ́, nítorí ìnilára àwọn eniyan burúkú; wọ́n kó ìyọnu bá mi, wọ́n ń bínú mi, inú wọn sì dùn láti máa bá mi ṣọ̀tá.

4 Ọkàn mi wà ninu ìrora, ìpayà ikú ti dé bá mi.

5 Ẹ̀rù ati ìwárìrì dà bò mí, ìpayà sì bò mí mọ́lẹ̀.

6 Mo ní, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà! Ǹ bá fò lọ, ǹ bá lọ sinmi.

7 Áà! Ǹ bá lọ jìnnà réré, kí n lọ máa gbé inú ijù;

8 ǹ bá yára lọ wá ibi ààbò kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ líle ati ìjì.”

9 Da èrò wọn rú, OLUWA, kí o sì dà wọ́n lédè rú; nítorí ìwà ipá ati asọ̀ pọ̀ ninu ìlú.

10 Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń yí orí odi rẹ̀ ká; ìwà ìkà ati ìyọnu ni ó sì pọ̀ ninu rẹ̀.

11 Ìparun wà ninu rẹ̀; ìnilára ati ìwà èrú kò sì kúrò láàrin ìgboro rẹ̀.

12 Bí ó bá ṣe pé ọ̀tá ní ń gàn mí, ǹ bá lè fara dà á. Bí ó bá ṣe pé ẹni tí ó kórìíra mi ní ń gbéraga sí mi, ǹ bá fara pamọ́ fún un.

13 Ṣugbọn ìwọ ni; ìwọ tí o jẹ́ irọ̀ mi, alábàárìn mi, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́.

14 À ti jọ máa sọ ọ̀rọ̀ dídùndídùn pọ̀ rí; a sì ti jọ rìn ní ìrẹ́pọ̀ ninu ilé Ọlọrun.

15 Jẹ́ kí ikú jí àwọn ọ̀tá mi pa; kí wọ́n lọ sinu isà òkú láàyè; kí wọ́n wọ ibojì lọ pẹlu ìpayà.

16 Ṣugbọn èmi ké pe Ọlọrun; OLUWA yóo sì gbà mí.

17 Mò ń ráhùn tọ̀sán-tòru, mo sì ń kérora; OLUWA óo gbọ́ ohùn mi.

18 Yóo yọ mí láìfarapa, ninu ogun tí mò ń jà, nítorí ọ̀pọ̀ ni àwọn tí wọ́n dojú kọ mí, tí wọn ń bá mi jà.

19 Ọlọrun tí ó gúnwà láti ìgbàanì yóo gbọ́, yóo sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí pé wọn kò pa ìwà wọn dà, wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọrun.

20 Alábàárìn mi gbógun ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó yẹ àdéhùn rẹ̀.

21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ dùn ju oyin lọ, bẹ́ẹ̀ sì ni ìjà ni ó wà lọ́kàn rẹ̀; ọ̀rọ̀ rẹ̀ tutù ju omi àmù lọ, ṣugbọn idà aṣekúpani ni.

22 Kó gbogbo ìṣòro rẹ lé OLUWA lọ́wọ́, yóo sì gbé ọ ró; kò ní jẹ́ kí á ṣí olódodo ní ipò pada.

23 Ṣugbọn ìwọ, Ọlọrun, o óo sọ àwọn apani ati àwọn alárèékérekè, sinu kòtò ìparun; wọn kò ní lo ìdajì ọjọ́ ayé wọn. Ṣugbọn èmi óo gbẹ́kẹ̀lé ọ.

56

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí pé àwọn eniyan ń lépa mi; ọ̀tá gbógun tì mí tọ̀sán-tòru.

2 Àwọn ọ̀tá ń lépa mi tọ̀sán-tòru, ọpọlọpọ ní ń bá mi jà tìgbéraga-tìgbéraga.

3 Nígbà tí ẹ̀rù bá ń bà mí, èmi yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4 Ọlọrun, mo yìn ọ́ fún ọ̀rọ̀ rẹ, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù; kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe?

5 Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń da ọ̀rọ̀ mi rú; ibi ni gbogbo èrò tí wọn ń gbà sí mi.

6 Wọ́n kó ara wọn jọ, wọ́n sápamọ́, wọ́n ń ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ mi, bí wọn ṣé ń dọdẹ ẹ̀mí mi.

7 Nítorí náà, san ẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn; ninu ibinu rẹ, Ọlọrun, ré àwọn eniyan yìí lulẹ̀.

8 O sá mọ gbogbo ìdààmú mi; ati bí omijé mi ti pọ̀ tó, wọ́n ṣá wà ní àkọsílẹ̀ ninu ìwé rẹ.

9 A óo lé àwọn ọ̀tá mi pada ní ọjọ́ tí mo bá ké pè ọ́. Mo mọ̀ dájú pé Ọlọrun ń bẹ fún mi.

10 Ọlọrun, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀, OLUWA, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀;

11 Ọlọrun ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù. Kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe?

12 Èmi óo san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ, Ọlọrun; n óo sì mú ẹbọ ọpẹ́ wá fún ọ.

13 Nítorí pé o ti gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ ikú, o gbà mí, o kò jẹ́ kí n kọsẹ̀, kí n lè máa rìn níwájú Ọlọrun ninu ìmọ́lẹ̀ ìyè.

57

1 Ṣàánú mi, Ọlọrun, ṣàánú mi, nítorí ìwọ ni ààbò mi; abẹ́ òjìji apá rẹ ni n óo fi ṣe ààbò mi, títí gbogbo àjálù wọnyi yóo fi kọjá.

2 Mo ké pe Ọlọrun Ọ̀gá Ògo, Ọlọrun tí ó mú èrò rẹ̀ ṣẹ fún mi.

3 Yóo ranṣẹ láti ọ̀run wá, yóo gbà mí là, yóo dójú ti àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi. Ọlọrun yóo fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ rẹ̀ hàn!

4 Ààrin àwọn kinniun ni mo dùbúlẹ̀ sí, àwọn tí ń jẹ eniyan ní ìjẹ ìwọ̀ra; eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ ati ọfà, ahọ́n wọn sì dàbí idà.

5 Gbé ara rẹ ga, Ọlọrun, gbé ara rẹ ga ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ sì tàn ká gbogbo ayé.

6 Wọ́n dẹ àwọ̀n sí ojú ọ̀nà mi; ìpọ́njú dorí mi kodò. Wọ́n gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí, ṣugbọn àwọn fúnra wọn ni wọ́n jìn sí i.

7 Ọkàn mi dúró ṣinṣin, Ọlọrun, ọkàn mi dúró ṣinṣin! N óo kọrin, n óo sì máa yìn ọ́.

8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Ẹ jí, ẹ̀yin ohun èlò orin, ati hapu, èmi alára náà yóo jí ní òwúrọ̀ kutukutu.

9 OLUWA, n óo máa fi ọpẹ́ fún ọ láàrin àwọn eniyan; n óo sì máa kọrin ìyìn sí ọ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.

10 Nítorí pé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi, ó ga ju ọ̀run lọ, òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

11 Gbé ara rẹ ga, Ọlọrun, gbé ara rẹ ga ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ sì tàn ká gbogbo ayé.

58

1 Ǹjẹ́ ìpinnu tí ẹ̀ ń ṣe tọ̀nà, ẹ̀yin aláṣẹ? Ǹjẹ́ ẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan ní ọ̀nà ẹ̀tọ́?

2 Rárá o! Ibi ni ẹ̀ ń fi ọkàn yín rò, iṣẹ́ burúkú ni ẹ sì ń fi ọwọ́ yín ṣe láyé.

3 Láti inú oyún ni àwọn eniyan burúkú ti ṣìnà, láti ọjọ́ tí a ti bí wọn ni wọ́n tí ń ṣìṣe, tí wọn ń purọ́.

4 Wọ́n ní oró bí oró ejò, wọ́n dití bíi paramọ́lẹ̀ tí ó di etí ara rẹ̀,

5 kí ó má baà gbọ́ ohùn afunfèrè, tabi ìpè adáhunṣe.

6 Kán eyín mọ́ wọn lẹ́nu, Ọlọrun; OLUWA! Yọ ọ̀gàn àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun.

7 Jẹ́ kí wọ́n rá, kí wọn ṣàn lọ bí omi; kí á tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bíi koríko, kí wọn sì rọ.

8 Kí wọn dàbí ìgbín tí a tẹ̀ ní àtẹ̀rẹ́, tí ó domi, ati bí òkúmọ tí kò fojú kan ìmọ́lẹ̀ ayé rí.

9 Lójijì, a ó ké eniyan burúkú lulẹ̀; ìjì ibinu Ọlọrun yóo sì gbá wọn lọ.

10 Olódodo yóo yọ̀ nígbà tí ẹ̀san bá ń ké, yóo fi ẹsẹ̀ wọ́ àgbàrá ẹ̀jẹ̀ àwọn eniyan burúkú.

11 Àwọn eniyan yóo wí nígbà náà pé, “Nítòótọ́, èrè ń bẹ fún olódodo; nítòótọ́, Ọlọrun ń bẹ tí ń ṣe ìdájọ́ ayé.”

59

1 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Ọlọrun mi; dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn tí ó gbógun tì mí.

2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn aṣebi, kí o sì yọ mí lọ́wọ́ àwọn apànìyàn.

3 Wò ó bí wọ́n ṣe lúgọ dè mí! OLUWA, àwọn jàǹdùkú eniyan kó ara wọn jọ láti pa mí lára, láìṣẹ̀, láìrò.

4 Láìjẹ́ pé mo ṣẹ̀, wọ́n ń sáré kiri, wọ́n múra dè mí. Paradà, wá ràn mí lọ́wọ́, kí o sì rí i fúnra rẹ.

5 Ìwọ, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli, jí gìrì, kí o jẹ gbogbo orílẹ̀-èdè níyà; má da ẹnìkan kan sí ninu àwọn tí ń fi ìwà ọ̀dàlẹ̀ pète ibi.

6 Ní alaalẹ́, wọn á pada wá, wọn á máa hu bí ajá, wọn a sì máa kiri ìlú.

7 Ẹ gbọ́ ohun tí wọn ń sọ jáde lẹ́nu, ẹ wo ahọ́n wọn bí idà; wọ́n sì ń wí ninu ara wọn pé, “Ta ni yóo gbọ́ ohun tí à ń sọ?”

8 Ṣugbọn ìwọ OLUWA ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín, o sì ń fi gbogbo orílẹ̀-èdè ṣe yẹ̀yẹ́.

9 Ọlọrun, agbára mi, ojú rẹ ni mò ń wò, nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi.

10 Ọlọrun mi óo wá sọ́dọ̀ mi ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀; Ọlọrun óo fún mi ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá mi.

11 Má pa wọ́n, kí àwọn eniyan mi má baà gbàgbé; fi ọwọ́ agbára rẹ mì wọ́n, ré wọn lulẹ̀, OLUWA, ààbò wa!

12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n fi ẹnu wọn dá, àní, nítorí ọ̀rọ̀ tí wọ́n fi ẹnu wọn sọ, jẹ́ kí ìgbéraga wọn kó bá wọn. Nítorí èpè tí wọ́n ṣẹ́ ati irọ́ tí wọ́n pa,

13 fi ibinu pa wọ́n run. Pa wọ́n run kí wọn má sí mọ́, kí àwọn eniyan lè mọ̀ pé Ọlọrun jọba lórí Jakọbu, ati títí dé òpin ayé.

14 Ní alaalẹ́ wọn á pada wá wọn á máa hu bí ajá, wọn á sì máa kiri ìlú.

15 Wọn á máa fẹsẹ̀ wọ́lẹ̀, wọn á máa wá oúnjẹ kiri, bí wọn ò bá sì yó wọn á máa kùn.

16 Ṣugbọn èmi ó kọrin ìyìn agbára rẹ; n óo kọrin sókè lówùúrọ̀, nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀. Nítorí ìwọ ni o ti jẹ́ odi mi ìwọ sì ni ààbò mi nígbà ìpọ́njú.

17 Ọlọrun, agbára mi, n óo kọ orin ìyìn fún ọ, nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi, Ọlọrun tí ó ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn mí.

60

1 Ọlọrun, o ti kọ̀ wá sílẹ̀, o ti wó odi wa; o ti bínú, dákun, mú wa bọ̀ sípò.

2 O ti mú kí ilẹ̀ mì tìtì; o ti mú kí ó yanu; dí gbogbo ibi tí ilẹ̀ ti ya, nítorí pé ó ń mì.

3 O ti jẹ́ kí àwọn eniyan rẹ ní ọpọlọpọ ìnira, o ti fún wa ní ọtí mu tóbẹ́ẹ̀ tí à ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n.

4 O ti ta àsíá ogun fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, kí wọ́n baà lè rí ààbò lọ́wọ́ ọfà ọ̀tá.

5 Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là, fi ọwọ́ agbára rẹ ṣẹgun fún wa, kí o sì dá wa lóhùn.

6 Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀, ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu, n óo sì pín àfonífojì Sukotu.

7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.

8 Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi; lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé; n óo sì hó ìhó ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistia.”

9 Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà? Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?

10 Ọlọrun, o kò ha ti kọ̀ wá sílẹ̀? Ọlọrun, o ò bá àwọn ọmọ ogun wa jáde lọ sójú ogun mọ́.

11 Ràn wá lọ́wọ́, bá wa gbógun ti àwọn ọ̀tá wa, nítorí pé asán ni ìrànlọ́wọ́ eniyan.

12 Pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọrun a óo ṣe akin, nítorí òun ni yóo tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

61

1 Gbọ́ igbe mi, Ọlọrun, fetí sí adura mi.

2 Láti ọ̀nà jíjìn réré ni mo ti ké pè ọ́, nígbà tí àárẹ̀ mú mi. Tọ́ mi lọ sí ibi àpáta tí ó ga jù mí lọ,

3 nítorí ìwọ ni ààbò mi, ìwọ ni ilé ìṣọ́ tí ó lágbára láti dáàbò bò mí lọ́wọ́ ọ̀tá.

4 Jẹ́ kí n máa gbé inú àgọ́ rẹ títí lae, kí n lè máa wà láìléwu lábẹ́ ààbò ìyẹ́ rẹ.

5 Nítorí ìwọ, Ọlọrun, ti gbọ́ ẹ̀jẹ́ tí mo jẹ́; o ti fún mi ní ogún tí o pèsè fún àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ rẹ.

6 Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba ó gùn; kí ó pẹ́ láyé kánrinkése.

7 Kí ó máa gúnwà níwájú Ọlọrun títí lae; máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, ati òtítọ́ rẹ ṣọ́ ọ.

8 Bẹ́ẹ̀ ni n óo máa kọ orin ìyìn orúkọ rẹ títí lae, nígbà tí mo bá ń san ẹ̀jẹ́ mi lojoojumọ.

62

1 Ọlọrun nìkan ni mo fi sùúrù gbẹ́kẹ̀lé; ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìgbàlà mi ti wá.

2 Òun nìkan ni àpáta ati olùgbàlà mi, òun ni odi mi, a kì yóo tì mí kúrò.

3 Yóo ti pẹ́ tó, tí gbogbo yín yóo dojú kọ ẹnìkan ṣoṣo, láti pa, ẹni tí kò lágbára ju ògiri tí ó ti fẹ́ wó lọ, tabi ọgbà tí ó fẹ́ ya?

4 Wọ́n fẹ́ ré e bọ́ láti ipò ọlá rẹ̀. Inú wọn a máa dùn sí irọ́. Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre, ṣugbọn ní ọkàn wọn, èpè ni wọ́n ń ṣẹ́.

5 Ọlọrun nìkan ni mo fi sùúrù gbẹ́kẹ̀lé, nítorí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìrètí mi ti wá.

6 Òun nìkan ni àpáta ati olùgbàlà mi, òun ni odi mi, a kì yóo tì mí kúrò.

7 Ọwọ́ Ọlọrun ni ìgbàlà ati ògo mi wà; òun ni àpáta agbára mi ati ààbò mi.

8 Ẹ gbẹ́kẹ̀lé e nígbà gbogbo, ẹ̀yin eniyan; ẹ tú ẹ̀dùn ọkàn yín palẹ̀ níwájú rẹ̀; OLUWA ni ààbò wa.

9 Afẹ́fẹ́ lásán ni àwọn mẹ̀kúnnù; ìtànjẹ patapata sì ni àwọn ọlọ́lá; bí a bá gbé wọn lé ìwọ̀n, wọn kò lè tẹ̀wọ̀n; àpapọ̀ wọn fúyẹ́ ju afẹ́fẹ́ lọ.

10 Má gbẹ́kẹ̀lé ìlọ́ni-lọ́wọ́-gbà, má sì fi olè jíjà yangàn; bí ọrọ̀ bá ń pọ̀ sí i, má gbé ọkàn rẹ lé e.

11 Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ níbìkan, mo sì ti gbọ́ ọ bí ìgbà mélòó kan pé, Ọlọrun ló ni agbára;

12 ati pé, tìrẹ, OLUWA ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀. Ò máa san ẹ̀san fún eniyan gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ bá ti rí.

63

1 Ọlọrun, ìwọ ni Ọlọrun mi, mò ń wá ọ, ọkàn rẹ ń fà mí; bí ilẹ̀ tí ó ti ṣá, tí ó sì gbẹ ṣe máa ń kóǹgbẹ omi.

2 Mo ti ń wò ọ́ ninu ilé mímọ́ rẹ, mo ti rí agbára ati ògo rẹ.

3 Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ dára ju ìyè lọ, n óo máa yìn ọ́.

4 N óo máa yìn ọ́ títí ayé mi; n óo máa tẹ́wọ́ adura sí ọ.

5 Ẹ̀mí mi yóo ní ànító ati àníṣẹ́kù; n óo sì fi ayọ̀ kọ orin ìyìn sí ọ.

6 Nígbà tí mo bá ranti rẹ lórí ibùsùn mi, tí mo bá ń ṣe àṣàrò nípa rẹ ní gbogbo òru;

7 nítorí ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi, lábẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ ni mò ń fi ayọ̀ kọrin.

8 Ẹ̀mí mi rọ̀ mọ́ ọ; ọwọ́ ọ̀tun rẹ ni ó gbé mi ró.

9 Ṣugbọn àwọn tí ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi yóo sọ̀kalẹ̀ lọ sinu isà òkú.

10 A ó fi idà pa wọ́n lójú ogun, ẹranko ni yóo sì jẹ òkú wọn.

11 Ṣugbọn ọba yóo máa yọ̀ ninu Ọlọrun; gbogbo àwọn tí ń fi orúkọ OLUWA búra yóo máa fògo fún un; ṣugbọn a ó pa àwọn òpùrọ́ lẹ́nu mọ́.

64

1 Ọlọrun, gbọ́ ìráhùn mi; pa mí mọ́ lọ́wọ́ ìdẹ́rùbà ọ̀tá;

2 dáàbò bò mí lọ́wọ́ ọ̀tẹ̀ àwọn eniyan burúkú; kó mi yọ lọ́wọ́ ète àwọn aṣebi.

3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà, wọ́n ń sọ̀kò ọ̀rọ̀ burúkú bí ẹni ta ọfà;

4 wọ́n ń sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí aláìṣẹ̀ láti ibùba wọn, láìbẹ̀rù, wọ́n ń ta ọfà ọ̀rọ̀ sí i lójijì.

5 Wọ́n wonkoko mọ́ ète burúkú wọn; wọ́n ń gbìmọ̀ àtidẹ okùn sílẹ̀ níkọ̀kọ̀, wọ́n ń rò lọ́kàn wọn pé, “Ta ni yóo rí wa?

6 Ta ni yóo wá ẹ̀ṣẹ̀ wa rí? Ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí ni a ti fi pète.” Áà, inú ọmọ eniyan jìn!

7 Ṣugbọn Ọlọrun yóo ta wọ́n lọ́fà; wọn óo fara gbọgbẹ́ lójijì.

8 Yóo pa wọ́n run nítorí ohun tí wọ́n fi ẹnu wọn sọ; gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn ni yóo máa mirí nítorí wọn.

9 Ẹ̀rù yóo sì ba gbogbo eniyan; wọn yóo máa sọ ohun tí Ọlọrun ti gbé ṣe, wọn yóo sì máa ronú nípa iṣẹ́ rẹ̀.

10 Kí àwọn olódodo máa yọ̀ ninu OLUWA, kí wọ́n sì máa wá ààbò lọ́dọ̀ rẹ̀! Kí gbogbo ẹni pípé máa ṣògo.

65

1 Ọlọrun, ìwọ ni ìyìn yẹ ní Sioni, ìwọ ni a óo san ẹ̀jẹ́ wa fún,

2 ìwọ tí ń gbọ́ adura! Ọ̀dọ̀ rẹ ni gbogbo eniyan ń bọ̀,

3 nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ wa bá borí wa, ìwọ a máa dáríjì wá.

4 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí o yàn, tí o mú wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, láti máa gbé inú àgbàlá rẹ. Àwọn ire inú ilé rẹ yóo tẹ́ wa lọ́rùn, àní, àwọn ire inú tẹmpili mímọ́ rẹ!

5 Iṣẹ́ òdodo tí ó bani lẹ́rù ni o fi dá wa lóhùn, Ọlọrun olùgbàlà wa. Ìwọ ni gbogbo àwọn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé gbẹ́kẹ̀lé, ati àwọn tí wọn wà lórí omi òkun ní ọ̀nà jíjìn réré.

6 Ìwọ tí o fi agbára fi ìdí àwọn òkè ńlá múlẹ̀; tí o sì fi agbára di ara rẹ ní àmùrè.

7 O mú híhó òkun dákẹ́ jẹ́ẹ́, ariwo ìgbì wọn rọlẹ̀ wọ̀ọ̀; o sì paná ọ̀tẹ̀ àwọn eniyan.

8 Àwọn tí ń gbé ìpẹ̀kun ayé sì ń bẹ̀rù nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ; o mú kí àwọn eniyan, láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀, hó ìhó ayọ̀.

9 Ò ń ṣìkẹ́ ayé, o sì ń bomi rin ín, o mú kí ilẹ̀ jí kí ó sì lẹ́tù lójú; o mú kí omi kún inú odò ìwọ Ọlọrun, o mú kí ọkà hù lórí ilẹ̀; nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni o ṣe ṣètò rẹ̀.

10 O bomi rin poro oko rẹ̀ lọpọlọpọ, o ṣètò àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀; o rọ òjò tó mú kí ilẹ̀ rọ̀, o sì mú kí ohun ọ̀gbìn rẹ̀ dàgbà.

11 O mú kí ìkórè oko pọ̀ yanturu ní òpin ọdún; gbogbo ipa ọ̀nà rẹ sì kún fún ọpọlọpọ ìkórè oko.

12 Gbogbo pápá oko kún fún ẹran ọ̀sìn, àwọn ẹ̀gbẹ́ òkè sì kún fún ohun ayọ̀,

13 ẹran ọ̀sìn bo pápá oko bí aṣọ, ọkà bo gbogbo àfonífojì, ó sì so jìngbìnnì, wọ́n ń hó, wọ́n sì ń kọrin ayọ̀.

66

1 Gbogbo ayé, ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọrun.

2 Ẹ kọ orin ògo yin orúkọ rẹ̀; ẹ yìn ín, ẹ fògo fún un!

3 Ẹ sọ fún Ọlọrun pé, “Iṣẹ́ rẹ bani lẹ́rù pupọ, agbára rẹ pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí àwọn ọ̀tá rẹ fi ń fi ìbẹ̀rù tẹríba fún ọ.

4 Gbogbo ayé ní ń sìn ọ́; wọ́n ń kọ orin ìyìn fún ọ, wọ́n ń kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.”

5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọrun ṣe, iṣẹ́ tí ó ń ṣe láàrin ọmọ eniyan bani lẹ́rù.

6 Ó sọ òkun di ìyàngbẹ ilẹ̀, àwọn eniyan fi ẹsẹ̀ rìn kọjá láàrin odò. Inú wa dùn níbẹ̀ nítorí ohun tí ó ṣe.

7 Nípa agbára rẹ̀ ó ń jọba títí lae. Ó ń ṣọ́ àwọn orílẹ̀-èdè lójú mejeeji, kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má gbéraga sí i.

8 Ẹ yin Ọlọrun wa, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, ẹ jẹ́ kí á gbọ́ ìró ìyìn rẹ̀;

9 ẹni tí ó dá wa sí tí a fi wà láàyè, tí kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa yẹ̀.

10 Nítorí ìwọ, Ọlọrun, ti dán wa wò; o ti dán wa wò bíi fadaka tí a dà ninu iná.

11 O jẹ́ kí á bọ́ sinu àwọ̀n; o sì di ẹrù wúwo lé wa lórí.

12 O jẹ́ kí àwọn eniyan máa gùn wá lórí mọ́lẹ̀, a ti la iná ati omi kọjá; sibẹsibẹ o mú wa wá sí ibi tí ilẹ̀ ti tẹ́jú.

13 N óo wá sinu ilé rẹ pẹlu ọrẹ ẹbọ sísun; n óo sì san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ.

14 Ẹ̀jẹ́ tí mo jẹ́, tí mo sì fi ẹnu mi sọ nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú.

15 N óo fi ẹran àbọ́pa rú ẹbọ sísun sí ọ, èéfín ẹbọ àgbò yóo rú sókè ọ̀run, n óo fi akọ mààlúù ati òbúkọ rúbọ.

16 Ẹ wá gbọ́, gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọrun, n óo sì ròyìn ohun tí ó ṣe fún mi.

17 Mo ké pè é, mo sì kọrin yìn ín.

18 Bí mo bá gba ẹ̀ṣẹ̀ láyè ní ọkàn mi, OLUWA ìbá tí gbọ́ tèmi.

19 Ṣugbọn nítòótọ́, Ọlọrun ti gbọ́; ó sì ti dáhùn adura mi.

20 Ìyìn ni fún Ọlọrun, nítorí pé kò kọ adura mi; kò sì mú kí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ kúrò lórí mi.

67

1 Kí Ọlọrun óo ṣàánú wa, kí ó bukun wa; kí ojú rẹ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí wa lára;

2 kí gbogbo ayé lè mọ ọ̀nà rẹ̀; kí gbogbo orílẹ̀-èdè sì mọ ìgbàlà rẹ̀.

3 Jẹ́ kí àwọn eniyan ó máa yìn ọ́, Ọlọrun; jẹ́ kí gbogbo eniyan máa yìn ọ́!

4 Kí inú àwọn orílẹ̀-èdè ó dùn, kí wọn ó máa kọrin ayọ̀, nítorí pé ò ń ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan láìṣe ojuṣaaju; o sì ń tọ́ gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ayé.

5 Jẹ́ kí àwọn eniyan ó máa yìn ọ́, Ọlọrun; jẹ́ kí gbogbo eniyan máa yìn ọ́!

6 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀ ìkórè jáde; Ọlọrun, àní Ọlọrun wa, bukun wa.

7 Ọlọrun bukun wa, kí gbogbo ayé máa bẹ̀rù rẹ̀.

68

1 Kí Ọlọrun dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ tú ká. Kí àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ sá níwájú rẹ̀.

2 Bí èéfín tií pòórá, bẹ́ẹ̀ ni kí wọn parẹ́; bí ìda tií yọ́ níwájú iná, bẹ́ẹ̀ ni kí àwọn eniyan burúkú parun níwájú Ọlọrun.

3 Ṣugbọn kí inú àwọn olódodo máa dùn, kí wọn máa yọ̀ níwájú Ọlọrun; kí wọn máa yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀.

4 Ẹ kọrin sí Ọlọrun, ẹ kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ̀, ẹ pòkìkí ẹni tí ń gun ìkùukùu lẹ́ṣin. OLUWA ni orúkọ rẹ̀; ẹ máa yọ̀ níwájú rẹ̀.

5 Baba àwọn aláìníbaba ati olùgbèjà àwọn opó ni Ọlọrun, ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́.

6 Ọlọrun, olùpèsè ibùjókòó fún àlejò tí ó nìkan wà; ẹni tí ó kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n jáde sinu ìdẹ̀ra, ṣugbọn ó sì fi àwọn ọlọ̀tẹ̀ sílẹ̀ ninu ilẹ̀ gbígbẹ.

7 Ọlọrun, nígbà tí ò ń jáde lọ níwájú àwọn eniyan rẹ, nígbà tí ò ń yan la aṣálẹ̀ já,

8 ilẹ̀ mì tìtì, ọ̀run pàápàá rọ òjò, níwájú Ọlọrun, Ọlọrun Sinai, àní, níwájú Ọlọrun Israẹli.

9 Ọlọrun, ọpọlọpọ ni òjò tí o rọ̀ sílẹ̀; o sì mú ilẹ̀ ìní rẹ tí ó ti gbẹ pada bọ̀ sípò.

10 Àwọn eniyan rẹ rí ibùgbé lórí rẹ̀; Ọlọrun, ninu oore ọwọ́ rẹ, o pèsè fún àwọn aláìní.

11 OLUWA fọhùn, ogunlọ́gọ̀ sì ni àwọn tí ó kéde ọ̀rọ̀ rẹ̀.

12 Gbogbo àwọn ọba ni ó sá tàwọn tọmọ ogun wọn; àwọn obinrin tí ó wà nílé,

13 ati àwọn tí ó wà ní ibùjẹ ẹran rí ìkógun pín: fadaka ni wọ́n yọ́ bo apá ère àdàbà; wúrà dídán sì ni wọ́n yọ́ bo ìyẹ́ rẹ̀.

14 Nígbà tí Olodumare tú àwọn ọba ká, ní òkè Salimoni, yìnyín bọ́.

15 Áà! Òkè Baṣani, òkè ńlá; Áà! Òkè Baṣani, òkè olórí pupọ.

16 Ẹ̀yin òkè olórí pupọ, kí ló dé tí ẹ̀ ń fi ìlara wo òkè tí Ọlọrun fẹ́ràn láti máa gbé, ibi tí OLUWA yóo máa gbé títí lae?

17 OLUWA sọ̀kalẹ̀ láti òkè Sinai sí ibi mímọ́ rẹ̀ pẹlu ẹgbẹẹgbẹrun lọ́nà ẹgbẹrun kẹ̀kẹ́ ogun, ẹgbẹẹgbẹrun lọ́nà ẹgbẹrun.

18 Ó gun òkè gíga, ó kó àwọn eniyan nígbèkùn; ó gba ẹ̀bùn lọ́wọ́ àwọn eniyan, ati lọ́wọ́ àwọn ọlọ̀tẹ̀ pàápàá. OLUWA Ọlọrun yóo máa gbébẹ̀.

19 Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun ìgbàlà wa, tí ń bá wa gbé ẹrù wa lojoojumọ.

20 Ọlọrun tí ń gbani là ni Ọlọrun wa; OLUWA Ọlọrun ni ń yọni lọ́wọ́ ikú.

21 Dájúdájú, OLUWA yóo fọ́ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀; yóo fọ́ àtàrí àwọn tí ń dẹ́ṣẹ̀.

22 OLUWA ní, “N óo kó wọn pada láti Baṣani, n óo kó wọn pada láti inú ibú omi òkun,

23 kí ẹ lè fi ẹsẹ̀ wọ́ àgbàrá ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá yín, kí àwọn ajá yín lè lá ẹ̀jẹ̀ wọn bí ó ti wù wọ́n.”

24 A ti rí ọ, Ọlọrun, bí o tí ń yan lọ, pẹlu ọ̀wọ́ èrò tí ń tẹ̀lé ọ lẹ́yìn. Ẹ wo Ọlọrun mi, ọba mi, bí ó ti ń yan wọ ibi mímọ́ rẹ̀,

25 àwọn akọrin níwájú, àwọn onílù lẹ́yìn, àwọn ọmọbinrin tí ń lu samba láàrin.

26 “Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọrun ninu àwùjọ eniyan, ẹ̀yin ìran Israẹli, ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA.”

27 Ẹ wo Bẹnjamini tí ó kéré jù níwájú, ẹ wo ogunlọ́gọ̀ àwọn ìjòyè Juda, ẹ wo àwọn ìjòyè Sebuluni ati ti Nafutali.

28 Fi agbára rẹ hàn, Ọlọrun, fi agbára tí o ti fi jà fún wa hàn.

29 Nítorí Tẹmpili rẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu, àwọn ọba yóo gbé ẹ̀bùn wá fún ọ.

30 Bá àwọn ẹranko ẹ̀dá tí ń gbé inú èèsún ní Ijipti wí; àwọn akọ mààlúù, láàrin agbo ẹran àwọn orílẹ̀-èdè. Tẹ àwọn tí ó fẹ́ràn owó mọ́lẹ̀; fọ́n àwọn orílẹ̀-èdè tí ó fẹ́ràn ogun ká.

31 Jẹ́ kí àwọn ikọ̀ wá láti Ijipti, kí àwọn ará Kuṣi tẹ́wọ́ adura sí Ọlọrun.

32 Ẹ kọ orin sí Ọlọrun ẹ̀yin ìjọba ayé; ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA.

33 Ẹni tí ń gun awọsanma lẹ́ṣin, àní awọsanma àtayébáyé; ẹ gbọ́ bí ó ṣe ń sán ààrá, ẹ gbọ́ ohùn alágbára.

34 Ẹ bu ọlá fún Ọlọrun, ẹni tí ògo rẹ̀ wà lórí Israẹli; tí agbára rẹ̀ sì hàn lójú ọ̀run.

35 Ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ni Ọlọrun ní ibi mímọ́ rẹ̀, Ọlọrun Israẹli; òun ni ó ń fún àwọn eniyan rẹ̀ ní ọlá ati agbára. Ìyìn ni fún Ọlọrun!

69

1 Gbà mí, Ọlọrun, nítorí omi ti mù mí dé ọrùn.

2 Mo ti rì sinu irà jíjìn, níbi tí kò ti sí ohun ìfẹsẹ̀tẹ̀; mo ti bọ́ sinu ibú, omi sì ti bò mí mọ́lẹ̀.

3 Mo sọkún títí àárẹ̀ mú mi, ọ̀nà ọ̀fun mi gbẹ, ojú mi sì di bàìbàì, níbi tí mo ti dúró, tí mò ń wo ojú ìwọ Ọlọrun mi.

4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí pọ̀, wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ. Àwọn tí ó fẹ́ pa mí run lágbára. Àwọn ọ̀tá mi ń parọ́ mọ́ mi, àwọn nǹkan tí n kò jí ni wọ́n ní kí n fi dandan dá pada.

5 Ọlọrun, o mọ ìwà òmùgọ̀ mi, àwọn àṣìṣe mi kò sì fara pamọ́ fún ọ.

6 Má tìtorí tèmi dójúti àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, má sì tìtorí mi sọ àwọn tí ń wá ọ di ẹni àbùkù, Ọlọrun Israẹli.

7 Nítorí tìrẹ ni mo ṣe di ẹni ẹ̀gàn, tí ìtìjú sì bò mí.

8 Mo ti di àlejò lọ́dọ̀ àwọn arakunrin mi, mo sì di àjèjì lọ́dọ̀ àwọn ọmọ ìyá mi.

9 Nítorí pé ìtara ilé rẹ ni ó jẹ mí lógún, ìwọ̀sí àwọn tí ó ń pẹ̀gàn rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.

10 Nígbà tí mo fi omijé gbààwẹ̀, ó di ẹ̀gàn fún mi.

11 Nígbà tí mò ń wọ aṣọ ọ̀fọ̀, mo di ẹni àmúpòwe.

12 Èmi ni àwọn tí ń jókòó lẹ́nu ibodè fi ń ṣe ọ̀rọ̀ sọ; àwọn ọ̀mùtí sì ń fi mí ṣe orin kọ.

13 Ṣugbọn ní tèmi, OLUWA, ìwọ ni mò ń gbadura sí ní àkókò tí ó bá yẹ, Ọlọrun, ninu ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, ninu agbára ìgbàlà rẹ, Ọlọrun dá mi lóhùn.

14 Yọ mí ninu irà yìí, má jẹ́ kí n rì, gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

15 Má jẹ́ kí ìgbì omi bò mí mọ́lẹ̀, kí ibú omi má gbé mi mì, kí isà òkú má sì padé mọ́ mi.

16 Dá mi lóhùn, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ dára; fojú rere wò mí, gẹ́gẹ́ bí ọpọlọpọ àánú rẹ.

17 Má ṣe fi ojú pamọ́ fún èmi, iranṣẹ rẹ, nítorí tí mo wà ninu ìdààmú, yára dá mi lóhùn.

18 Sún mọ́ mi, rà mí pada, kí o sì tú mi sílẹ̀ nítorí àwọn ọ̀tá mi!

19 O mọ ẹ̀gàn mi, o mọ ìtìjú ati àbùkù mi; o sì mọ gbogbo àwọn ọ̀tá mi.

20 Ẹ̀gàn ti mú kí inú mi bàjẹ́, tóbẹ́ẹ̀ tí ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì mò ń retí àánú ṣugbọn kò sí; mò ń retí olùtùnú, ṣugbọn n kò rí ẹnìkan.

21 Iwọ ni wọ́n sọ di oúnjẹ fún mi, nígbà tí òùngbẹ sì ń gbẹ mí, ọtí kíkan ni wọ́n fún mi mu.

22 Jẹ́ kí tabili oúnjẹ tí wọ́n tẹ́ fún ara wọn di ẹ̀bìtì fún wọn; kí àsè ẹbọ wọn sì di tàkúté.

23 Jẹ́ kí ojú wọn ṣú, kí wọn má lè ríran; kí gbogbo ara wọn sì máa gbọ̀n rìrì.

24 Rọ òjò ibinu rẹ lé wọn lórí, kí o sì jẹ́ kí wọ́n rí gbígbóná ibinu rẹ.

25 Kí ibùdó wọn ó di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má sì gbé inú àgọ́ wọn.

26 Nítorí ẹni tí o ti kọlù ni wọ́n tún gbógun tì; ẹni tí o ti ṣá lọ́gbẹ́ ni wọ́n sì tún ń pọ́n lójú.

27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; má sì jẹ́ kí wọ́n rí ìdáláre lọ́dọ̀ rẹ.

28 Pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò ninu ìwé ìyè; kí á má sì kọ orúkọ wọn mọ́ ti àwọn olódodo.

29 Ojú ń pọ́n mi, mo sì ń jẹ̀rora; Ọlọrun, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè!

30 Èmi ó fi orin yin orúkọ Ọlọrun; n óo fi ọpẹ́ gbé e ga.

31 Èyí yóo tẹ́ Ọlọrun lọ́rùn ju akọ mààlúù lọ, àní, akọ mààlúù tòun tìwo ati pátákò rẹ̀.

32 Àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóo rí i, inú wọn yóo dùn; ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wá Ọlọrun, ẹ jẹ́ kí ọkàn yín sọjí.

33 Nítorí OLUWA a máa gbọ́ ti àwọn aláìní, kì í sìí kẹ́gàn àwọn eniyan rẹ̀ tí ó wà ní ìgbèkùn.

34 Jẹ́ kí ọ̀run ati ayé kí ó yìn ín, òkun ati gbogbo ohun tí ó ń rìn káàkiri ninu wọn.

35 Nítorí Ọlọrun yóo gba Sioni là; yóo sì tún àwọn ìlú Juda kọ́; àwọn iranṣẹ rẹ̀ yóo máa gbé inú rẹ̀, yóo sì di tiwọn.

36 Àwọn ọmọ àwọn iranṣẹ rẹ̀ yóo jogún rẹ̀; àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ̀ yóo sì máa gbé inú rẹ̀.

70

1 Ọlọrun, dákun, gbà mí, yára, OLUWA, ràn mí lọ́wọ́.

2 Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí wọn fẹ́ gba ẹ̀mí mi kí ìdàrúdàpọ̀ bá wọn; jẹ́ kí á lé àwọn tí ń wá ìpalára mi pada sẹ́yìn, kí wọn sì tẹ́.

3 Jẹ́ kí jìnnìjìnnì bo àwọn tí ń yọ̀ mí, tí ń ṣe jàgínní mi; kí wọn sì gba èrè ìtìjú.

4 Kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ máa yọ̀ nítorí rẹ, kí inú wọn sì máa dùn, kí àwọn tí ó fẹ́ràn ìgbàlà rẹ máa wí nígbà gbogbo pé, “Ọlọrun tóbi!”

5 Ṣugbọn ní tèmi, olùpọ́njú ati aláìní ni mí, yára wá sọ́dọ̀ mi, Ọlọrun! Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi ati olùgbàlà mi, má pẹ́ OLÚWA.

71

1 OLUWA, ìwọ ni mo sá di; má jẹ́ kí ojú ó tì mí laelae!

2 Gbà mí, kí o sì yọ mí nítorí òdodo rẹ; tẹ́tí sí mi kí o sì gbà mí là!

3 Máa ṣe àpáta ààbò fún mi, jẹ́ odi alágbára fún mi kí o sì gbà mí, nítorí ìwọ ni ààbò ati odi mi.

4 Ọlọrun mi, gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú, àwọn alaiṣootọ ati ìkà.

5 Nítorí ìwọ OLUWA, ni ìrètí mi, OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láti ìgbà èwe mi.

6 Ìwọ ni mo gbára lé láti inú oyún; ìwọ ni o mú mi jáde láti inú ìyá mi. Ìwọ ni n óo máa yìn nígbà gbogbo.

7 Mo di ẹni àmúpòwe fún ọpọlọpọ eniyan, ṣugbọn ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.

8 Ẹnu mi kún fún ìyìn rẹ, ó kún fún ògo rẹ tọ̀sán-tòru.

9 Má ta mí nù ní ìgbà ogbó mi; má sì gbàgbé mi nígbà tí n kò bá lágbára mọ́.

10 Nítorí pé àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi, àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi ti pàmọ̀ pọ̀,

11 wọ́n ní, “Ọlọrun ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; ẹ lé e, ẹ mú un; nítorí kò sí ẹni tí yóo gbà á sílẹ̀ mọ́.”

12 Ọlọrun, má jìnnà sí mi; yára, Ọlọrun mi, ràn mí lọ́wọ́!

13 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn alátakò mi, kí wọn parun; kí ẹ̀gàn ati ìtìjú bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14 Ní tèmi, èmi ó máa ní ìrètí nígbà gbogbo, n óo sì túbọ̀ máa yìn ọ́.

15 N óo máa ṣírò iṣẹ́ rere rẹ, n óo máa ròyìn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ tọ̀sán-tòru, nítorí wọ́n pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tí n kò lè mọ iye wọn.

16 N óo wá ninu agbára OLUWA Ọlọrun, n óo máa kéde iṣẹ́ òdodo rẹ, àní, iṣẹ́ òdodo tìrẹ nìkan.

17 Ọlọrun, láti ìgbà èwe mi ni o ti kọ́ mi, títí di òní ni mo sì ń polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ,

18 Nisinsinyii tí mo ti dàgbà, tí ewú sì ti gba orí mi, Ọlọrun, má kọ̀ mí sílẹ̀, títí tí n óo fi ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ, àní, iṣẹ́ agbára rẹ, fún gbogbo àwọn ìran tí ń bọ̀.

19 Ọlọrun, iṣẹ́ òdodo rẹ kan ojú ọ̀run, ìwọ tí o ṣe nǹkan ńlá, Ọlọrun, ta ni ó dàbí rẹ?

20 O ti jẹ́ kí n rí ọpọlọpọ ìpọ́njú ńlá, ṣugbọn óo tún mú ìgbé ayé mi pada bọ̀ sípò; óo tún ti gbé mi dìde láti inú isà òkú.

21 O óo fi kún ọlá mi, o óo sì tún tù mí ninu.

22 Èmi náà óo máa fi hapu yìn ọ́, nítorí òtítọ́ rẹ, Ọlọrun mi; n óo máa fi ohun èlò orin yìn ọ́, ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.

23 N óo máa kígbe fún ayọ̀, nígbà tí mo bá ń kọ orin ìyìn sí ọ; ẹ̀mí mi tí o ti kó yọ, yóo ké igbe ayọ̀.

24 Ẹnu mi yóo ròyìn iṣẹ́ rẹ tọ̀sán-tòru, nítorí a ti ṣẹgun àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì ti dójú tì wọ́n.

72

1 Ọlọrun, gbé ìlànà òtítọ́ rẹ lé ọba lọ́wọ́; kọ́ ọmọ ọba ní ọ̀nà òdodo rẹ.

2 Kí ó lè máa fi òdodo ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan rẹ, kí ó sì máa dá ẹjọ́ àwọn tí ìyà ń jẹ ní ọ̀nà ẹ̀tọ́;

3 kí àwọn eniyan tí ó gbé orí òkè ńlá lè rí alaafia, kí nǹkan sì dára fún àwọn tí ń gbé orí òkè kéékèèké.

4 Jẹ́ kí ó máa gbèjà àwọn eniyan tí ìyà ń jẹ; kí ó máa gba àwọn ọmọ talaka sílẹ̀; kí ó sì rún àwọn aninilára wómúwómú.

5 Ọlọrun, jẹ́ kí àwọn eniyan rẹ máa bẹ̀rù rẹ láti ìran dé ìran, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn bá ń ràn, tí òṣùpá sì ń yọ.

6 Jẹ́ kí ọba ó dàbí òjò tí ó rọ̀ sórí koríko tí a ti gé àní, bí ọ̀wààrà òjò tí ń rin ilẹ̀.

7 Kí ìwà rere ó gbèrú ní ìgbà tirẹ̀; kí alaafia ó gbilẹ̀ títí tí òṣùpá kò fi ní yọ mọ́.

8 Kí ìjọba rẹ̀ ó lọ láti òkun dé òkun, ati láti odò ńlá títí dé òpin ayé.

9 Àwọn tí ń gbé aṣálẹ̀ yóo máa foríbalẹ̀ fún un; àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóo sì máa fi ẹnu gbo ilẹ̀ níwájú rẹ̀.

10 Àwọn ọba Taṣiṣi ati àwọn ọba erékùṣù gbogbo yóo máa san ìṣákọ́lẹ̀ fún un; àwọn ọba Ṣeba ati ti Seba yóo máa mú ẹ̀bùn wá.

11 Gbogbo àwọn ọba yóo máa wólẹ̀ fún un; gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóo sì máa sìn ín.

12 Nítorí pé a máa gba talaka tí ó bá ké pè é sílẹ̀; a sì máa gba àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀, ati àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

13 A máa ṣíjú àánú wo àwọn aláìní ati talaka, a sì máa gba àwọn talaka sílẹ̀.

14 A máa gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn aninilára ati oníwà ipá, ẹ̀mí wọn sì ṣe iyebíye ní ojú rẹ̀.

15 Ẹ̀mí rẹ̀ yóo gùn, a óo máa fi wúrà Ṣeba ta á lọ́rẹ, a óo máa gbadura fún un nígbà gbogbo; a óo sì máa súre fún un tọ̀sán-tòru.

16 Ọkà yóo pọ̀ lóko, yóo máa mì lẹ̀gbẹ̀ lórí òkè; èso rẹ̀ yóo dàbí ti Lẹbanoni, eniyan yóo pọ̀ ní ìlú, bíi koríko ninu pápá.

17 Orúkọ ọba óo wà títí lae, òkìkí rẹ̀ óo sì máa kàn níwọ̀n ìgbà tí oòrùn bá ń ràn; àwọn eniyan óo máa fi orúkọ rẹ̀ súre fún ara wọn, gbogbo orílẹ̀-èdè óo sì máa pè é ní olóríire.

18 Ẹni-ìyìn ni OLUWA Ọlọrun Israẹli, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìyanu tí ẹlòmíràn kò lè ṣe.

19 Ẹni ìyìn títí lae ni ẹni tí orúkọ rẹ̀ lókìkí, kí òkìkí rẹ̀ gba ayé kan! Amin! Amin.

20 Níbi tí adura Dafidi ọmọ Jese parí sí nìyí.

73

1 Nítòótọ́ Ọlọrun ṣeun fún Israẹli, ó ṣeun fún àwọn tí ọkàn wọn mọ́.

2 Ṣugbọn, ní tèmi, mo fẹ́rẹ̀ yọ̀ ṣubú, ẹsẹ̀ mi fẹ́rẹ̀ tàsé.

3 Nítorí mò ń ṣe ìlara àwọn onigbeeraga nígbà tí mo rí ọrọ̀ àwọn eniyan burúkú.

4 Wọn kì í jẹ ìrora kankan, ara wọn dá pé, ó sì jọ̀lọ̀.

5 Wọn kì í ní wahala bí àwọn ẹlòmíràn; ìyọnu tíí dé bá àwọn ẹlòmíràn kì í dé ọ̀dọ̀ wọn.

6 Nítorí náà, wọn á kó ìgbéraga bọ ọrùn bí ẹ̀gbà, wọn á fi ìwà ipá bora bí aṣọ.

7 Wọ́n sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú wọn yíbò; èrò òmùgọ̀ sì kún ọkàn wọn ní àkúnwọ́sílẹ̀.

8 Wọ́n ń pẹ̀gàn eniyan, wọ́n ń sọ̀rọ̀ pẹlu ìlara; wọ́n sì ń fi ìgbéraga halẹ̀.

9 Wọ́n ń fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ òdì sí Ọlọrun; wọn a sì máa sọ̀rọ̀ ìgbéraga káàkiri ayé.

10 Nítorí náà, àwọn eniyan á yipada, wọn á fara mọ́ wọn, wọn á máa yìn wọ́n, láìbìkítà fún ibi tí wọn ń ṣe.

11 Wọn á máa wí pé, “Báwo ni Ọlọrun ṣe lè mọ̀? Ǹjẹ́ Ọ̀gá Ògo tilẹ̀ ní ìmọ̀?”

12 Ẹ wò ó! Ayé àwọn eniyan burúkú nìwọ̀nyí; ara dẹ̀ wọ́n nígbà gbogbo, ọrọ̀ wọn sì ń pọ̀ sí i.

13 Lásán ni gbogbo aáyan mi láti rí i pé ọkàn mi mọ́, tí mo sì yọwọ́-yọsẹ̀ ninu ibi.

14 Nítorí pé tọ̀sán-tòru ni mò ń rí ìyọnu; láràárọ̀ ni à ń jẹ mí níyà.

15 Bí mo bá ní, “N óo sọ̀rọ̀ báyìí,” n óo kó àwọn ọmọ rẹ ṣìnà.

16 Ṣugbọn nígbà tí mo rò bí nǹkan wọnyi ṣe lè yé mi, mo rí i pé iṣẹ́ tíí dáni lágara ni.

17 Àfi ìgbà tí mo wọ ibi mímọ́ Ọlọrun lọ, ni mo tó wá rí òye ìgbẹ̀yìn wọn.

18 Nítòótọ́ ibi tí ń yọ̀ ni ó gbé wọn lé, ó sì mú kí wọn ṣubú sinu ìparun.

19 Wò ó bí wọn ṣe parun lọ́gán, tí ìpayà sì gbá wọn lọ patapata.

20 Wọ́n dàbí àlá tíí pòórá nígbà tí eniyan bá ta jí. OLUWA, nígbà tí o bá jí gìrì, wọn óo pòórá.

21 Nígbà tí ọkàn mí bàjẹ́, tí ọ̀rọ̀ náà gbóná lára mi,

22 mo hùwà òmùgọ̀, n kò sì lóye, mo sì dàbí ẹranko lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ.

23 Sibẹsibẹ nígbà gbogbo ni mo wà lọ́dọ̀ rẹ; o sì di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.

24 Ò ń fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi sọ́nà; lẹ́yìn náà, o óo sì gbà mí sinu ògo.

25 Ta ni mo ní lọ́run lẹ́yìn rẹ? Kò sì sí ohun kan tí ó wù mí láyé yìí bíkòṣe ìwọ.

26 Àárẹ̀ lè mú ara ati ẹ̀mí mi, ṣugbọn Ọlọrun ni agbára ẹ̀mí mi, ati ìpín mi títí lae.

27 Ó dájú pé àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóo ṣègbé, o óo sì pa àwọn tí ó bá ṣe alaiṣootọ sí ọ run.

28 Ní tèmi o, ó dára láti súnmọ́ Ọlọrun; mo ti fi ìwọ OLUWA Ọlọrun ṣe ààbò mi, kí n lè máa ròyìn gbogbo iṣẹ́ rẹ.

74

1 Ọlọrun, kí ló dé tí o fi ta wá nù títí ayé? Kí ló dé tí inú rẹ fi ń ru sí àwa aguntan pápá rẹ?

2 Ranti ìjọ eniyan rẹ tí o ti rà ní ìgbà àtijọ́, àwọn ẹ̀yà tí o rà pada láti fi ṣe ogún tìrẹ; ranti òkè Sioni níbi tí o ti ń gbé rí.

3 Rìn káàkiri kí o wo bí gbogbo ilẹ̀ ti di ahoro, wo bí ọ̀tá ti ba gbogbo nǹkan jẹ́ ninu ibi mímọ́ rẹ.

4 Àwọn ọ̀tá rẹ bú ramúramù ninu ilé ìsìn rẹ; wọ́n ta àsíá wọn gẹ́gẹ́ bí àmì ìṣẹ́gun.

5 Wọ́n dàbí ẹni tí ó gbé àáké sókè, tí ó fi gé igi ìṣẹ́pẹ́.

6 Gbogbo pákó tí a fi dárà sí ara ògiri ni wọ́n fi àáké ati òòlù fọ́.

7 Wọ́n jó ibi mímọ́ rẹ kanlẹ̀; wọ́n sì ba ilé tí a ti ń pe orúkọ rẹ jẹ́.

8 Wọ́n pinnu lọ́kàn wọn pé, “A óo bá wọn kanlẹ̀ patapata.” Wọ́n dáná sun gbogbo ilé ìsìn Ọlọrun tí ó wà ní ilẹ̀ náà.

9 A kò rí àsíá wa mọ́, kò sí wolii mọ́; kò sì sí ẹnìkan ninu wa tí ó mọ bí ìṣòro wa yóo ti pẹ́ tó.

10 Yóo ti pẹ́ tó, Ọlọrun, tí ọ̀tá yóo máa fi ọ́ ṣẹ̀fẹ̀? Ṣé títí ayé ni ọ̀tá yóo máa gan orúkọ rẹ ni?

11 Kí ló dé tí o ò ṣe nǹkankan? Kí ló dé tí o káwọ́ gbera?

12 Ọlọrun, ìwọ ṣá ni ọba wa láti ìbẹ̀rẹ̀ wá; ìwọ ni o máa ń gbà wá là láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè.

13 Ìwọ ni o fi agbára rẹ pín òkun níyà; o fọ́ orí àwọn ẹranko ńlá inú omi.

14 Ìwọ ni o fọ́ orí Lefiatani túútúú; o sì fi òkú rẹ̀ ṣe ìjẹ fún àwọn ẹranko inú aṣálẹ̀.

15 Ìwọ ni o fọ́ àpáta tí omi tú jáde, tí odò sì ń ṣàn, ìwọ ni o sọ odò tí ń ṣàn di ilẹ̀ gbígbẹ.

16 Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ náà sì ni òru, ìwọ ni o gbé òṣùpá ati oòrùn ró.

17 Ìwọ ni o pa gbogbo ààlà ilẹ̀ ayé; ìwọ ni o dá ìgbà òjò ati ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn.

18 OLUWA, ranti pé àwọn ọ̀tá ń fi ọ́ ṣe yẹ̀yẹ́; àwọn òmùgọ̀ eniyan sì ń fi orúkọ rẹ ṣe ẹlẹ́yà.

19 Má fi ẹ̀mí àwa àdàbà rẹ lé àwọn ẹranko lọ́wọ́; má sì gbàgbé àwa eniyan rẹ tí ìyà ń jẹ títí lae.

20 Ranti majẹmu rẹ; nítorí pé gbogbo kọ̀rọ̀ ilẹ̀ wa kún fún ìwà ipá.

21 Má jẹ́ kí ojú ti àwọn tí à ń pọ́n lójú; jẹ́ kí àwọn tí ìyà ń jẹ ati àwọn aláìní máa yin orúkọ rẹ.

22 Dìde Ọlọrun, gbèjà ara rẹ; ranti bí àwọn òmùgọ̀ eniyan tí ń fi ọ́ ṣe yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru.

23 Má gbàgbé ariwo àwọn ọ̀tá rẹ; àní, igbe àwọn tí ó gbógun tì ọ́, tí wọn ń ké láìdá ẹnu dúró.

75

1 A dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Ọlọrun; a dúpẹ́. À ń kéde orúkọ rẹ, a sì ń ròyìn iṣẹ́ ribiribi tí o ṣe.

2 OLUWA ní, “Nígbà tí àkókò tí mo yà sọ́tọ̀ bá tó, n óo ṣe ìdájọ́ pẹlu àìṣojúṣàájú.

3 Nígbà tí ayé bá ń mì síhìn-ín sọ́hùn-ún, ati gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀; èmi a mú kí òpó rẹ̀ dúró wámúwámú.

4 Èmi a sọ fún àwọn tí ń fọ́nnu pé, ‘Ẹ yé fọ́nnu’; èmi a sì sọ fún àwọn eniyan burúkú pé, ‘Ẹ yé ṣe ìgbéraga.’

5 Ẹ má halẹ̀ ju bí ó ti yẹ lọ, ẹ má sì gbéraga.”

6 Nítorí pé kì í ṣe láti ìlà oòrùn, tabi láti ìwọ̀ oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í ṣe apá gúsù tabi àríwá ni ìgbéga tií wá.

7 Ọlọrun níí dájọ́ bí ó ti wù ú: á rẹ ẹnìkan sílẹ̀, á sì gbé ẹlòmíràn ga.

8 Ife kan wà ní ọwọ́ OLUWA, Ibinu Oluwa ló kún inú rẹ̀, ó ń ru bí ọtí àní bí ọtí tí a ti lú, yóo ṣẹ́ ninu rẹ̀; gbogbo àwọn eniyan burúkú ilẹ̀ ayé ni yóo sì mu ún, wọn óo mu ún tán patapata tòun ti gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀.

9 Ṣugbọn èmi óo máa yọ̀ títí lae, n óo kọ orin ìyìn sí Ọlọrun Jakọbu.

10 Ọlọrun yóo gba gbogbo agbára ọwọ́ àwọn eniyan burúkú kúrò; ṣugbọn yóo fi agbára kún agbára fún àwọn olódodo.

76

1 Àwọn ará Juda mọ Ọlọrun, orúkọ rẹ̀ sì lọ́wọ̀ ní Israẹli.

2 Ilé rẹ̀ wà ní Salẹmu, ibùgbé rẹ̀ wà ní Sioni.

3 Níbẹ̀ ni ó ti ṣẹ́ ọfà ọ̀tá tí ń rọ̀jò, ati apata, ati idà, ati àwọn ohun ìjà ogun.

4 Ológo ni ọ́, ọlá rẹ sì pọ̀, ó ju ti àwọn òkè tí ó kún fún ẹran lọ.

5 A gba ìkógun lọ́wọ́ àwọn akikanju, wọ́n sun oorun àsùn-ùn-jí; àwọn alágbára kò sì le gbé ọwọ́ láti jà.

6 Nípa ìbáwí rẹ, Ọlọrun Jakọbu, ati ẹṣin, ati ẹni tó gun ẹṣin, gbogbo wọn ló ṣubú lulẹ̀, tí wọn kò sì lè mira.

7 Ṣugbọn ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ni ọ́! Ta ló tó dúró níwájú rẹ tí ibinu rẹ bá dé?

8 Láti ọ̀run wá ni o ti ń ṣe ìdájọ́, ẹ̀rù ba ayé, ayé sì dúró jẹ́ẹ́;

9 nígbà tí Ọlọrun dìde láti gbé ìdájọ́ kalẹ̀, láti gba gbogbo àwọn tí à ń nilára láyé sílẹ̀.

10 Dájúdájú ibinu eniyan yóo pada di ìyìn fún ọ; àwọn tí wọ́n bá sì bọ́ lọ́wọ́ ibinu rẹ yóo ṣe àjọ̀dún rẹ.

11 Jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún OLUWA Ọlọrun rẹ, kí o sì mú un ṣẹ, kí gbogbo àwọn tí ó yí i ká mú ẹ̀bùn wá fún ẹni tí ó yẹ kí á bẹ̀rù.

12 Ẹni tí ń gba ẹ̀mí àwọn ìjòyè, tí ó ń ṣe ẹ̀rù ba àwọn ọba ayé.

77

1 Mo ké pe Ọlọrun fún ìrànlọ́wọ́, mo kígbe pe Ọlọrun kí ó lè gbọ́ tèmi.

2 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi, mo wá OLUWA; ní òru, mo tẹ́wọ́ adura láìkáàárẹ̀, ṣugbọn n kò rí ìtùnú.

3 Mo ronú nípa Ọlọrun títí, mò ń kérora; mo ṣe àṣàrò títí, ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì.

4 OLUWA, o ò jẹ́ kí n dijú wò ní gbogbo òru mo dààmú tóbẹ́ẹ̀ tí n kò le sọ̀rọ̀.

5 Mo ranti ìgbà àtijọ́, mo ranti ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn.

6 Mo ronú jinlẹ̀ lóru, mo ṣe àṣàrò, mo yẹ ọkàn mi wò.

7 Ṣé Ọlọrun yóo kọ̀ wá sílẹ̀ títí lae ni; àbí inú rẹ̀ kò tún ní dùn sí wa mọ́?

8 Ṣé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ti pin títí lae ni; àbí ìlérí rẹ̀ ti dópin patapata?

9 Ṣé Ọlọrun ti gbàgbé láti máa ṣoore ni; àbí ó ti fi ibinu pa ojú àánú rẹ̀ dé?

10 Nígbà náà ni mo wí pé, “Ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́ ni pé Ọ̀gá Ògo kò jẹ́wọ́ agbára mọ́.”

11 N óo ranti àwọn iṣẹ́ OLUWA, àní, n óo ranti àwọn iṣẹ́ ìyanu ìgbàanì.

12 N óo máa ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ; n óo sì máa ronú lórí àwọn iṣẹ́ ribiribi tí o ṣe.

13 Ọlọrun, mímọ́ ni ọ̀nà rẹ; oriṣa wo ni ó tó Ọlọrun wa?

14 Ìwọ ni Ọlọrun tí ń ṣe ohun ìyanu; o ti fi agbára rẹ hàn láàrin àwọn eniyan.

15 O ti fi agbára rẹ gba àwọn eniyan rẹ là; àní, àwọn ọmọ Jakọbu ati Josẹfu.

16 Nígbà tí omi òkun rí ọ, Ọlọrun, àní, nígbà tí omi òkun fi ojú kàn ọ́, ẹ̀rù bà á; ibú omi sì wárìrì.

17 Ìkùukùu da omi òjò sílẹ̀, ojú ọ̀run sán ààrá; mànàmáná ń kọ yẹ̀rì káàkiri.

18 Ààrá ń sán kíkankíkan ní ojú ọ̀run, mànàmáná ń kọ yànràn, gbogbo ayé sì mọ́lẹ̀; ilẹ̀ ayé wárìrì, ó sì mì tìtì.

19 Ọ̀nà rẹ wà lójú omi òkun, ipa ọ̀nà rẹ la omi òkun ńlá já; sibẹ ẹnìkan kò rí ipa ẹsẹ̀ rẹ.

20 O kó àwọn eniyan rẹ jáde bí agbo ẹran, o fi Mose ati Aaroni ṣe olórí wọn.

78

1 Ẹ̀yin eniyan mi, ẹ dẹtí sí ẹ̀kọ́ mi; ẹ tẹ́tí si ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

2 N óo la ẹnu mi tòwe-tòwe; n óo fa ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àtijọ́ yọ,

3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba ńlá wa ti sọ fún wa.

4 A kò ní fi pamọ́ fún àwọn ọmọ wọn; a óo máa sọ ọ́ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ lẹ́yìn– iṣẹ́ ńlá OLUWA ati ìṣe akọni rẹ̀, ati iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe.

5 Ó fi ìlànà lélẹ̀ fún ìdílé Jakọbu; ó gbé òfin kalẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa á láṣẹ fún àwọn baba ńlá wa, pé kí wọ́n fi kọ́ àwọn ọmọ wọn.

6 Kí àwọn ìran tí ń bọ̀ lè mọ̀ ọ́n, àní, àwọn ọmọ tí a kò tíì bí, kí àwọn náà ní ìgbà tiwọn lè sọ ọ́ fún àwọn ọmọ wọn.

7 Kí wọn lè gbẹ́kẹ̀lé Ọlọrun, kí wọn má gbàgbé iṣẹ́ rẹ̀, kí wọn sì máa pa òfin rẹ̀ mọ́,

8 kí wọn má dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran àwọn olóríkunkun ati ọlọ̀tẹ̀, àwọn tí ọkàn wọn kò dúró ṣinṣin, tí ẹ̀mí wọn kò sì dúró gbọningbọnin ti Olodumare.

9 Àwọn ọmọ Efuraimu kó ọrun, wọ́n kó ọfà, ṣugbọn wọ́n pẹ̀yìndà lọ́jọ́ ìjà.

10 Wọn kò pa majẹmu Ọlọrun mọ́, wọ́n kọ̀, wọn kò jẹ́ pa òfin rẹ̀ mọ́.

11 Wọ́n gbàgbé iṣẹ́ rẹ̀, ati iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe hàn wọ́n.

12 Ní ìṣojú àwọn baba ńlá wọn, ó ṣe ohun ìyanu, ní ilẹ̀ Ijipti, ní oko Soani.

13 Ó pín òkun níyà, ó jẹ́ kí wọ́n kọjá láàrin rẹ̀; ó sì mú kí omi nàró bí òpó ńlá.

14 Ó fi ìkùukùu ṣe atọ́nà wọn ní ọ̀sán, ó fi ìmọ́lẹ̀ iná tọ́ wọn sọ́nà ní gbogbo òru.

15 Ó la àpáta ni aṣálẹ̀, ó sì fún wọn ní omi mu lọpọlọpọ bí ẹni pé láti inú ibú.

16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta; ó sì mú kí ó ṣàn bí odò.

17 Sibẹsibẹ wọn ò dẹ́kun ẹ̀ṣẹ̀ dídá; wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo ninu aṣálẹ̀.

18 Wọ́n dán Ọlọrun wò ninu ọkàn wọn, wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóo tẹ́ ìfẹ́ ọkàn wọn lọ́rùn.

19 Wọ́n sọ̀rọ̀ ìwọ̀sí sí Ọlọrun, wọ́n ní, “Ṣé Ọlọrun lè gbé oúnjẹ kalẹ̀ fún wa ninu aṣálẹ̀?

20 Lóòótọ́ ó lu òkúta tí omi fi tú jáde, tí odò sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn. Ṣé ó lè fún wa ní òkèlè pẹlu, àbí ó lè pèsè ẹran fún àwọn eniyan rẹ̀?”

21 Nítorí náà nígbà tí OLUWA gbọ́, inú bí i; iná mọ́ ìdílé Jakọbu, inú OLUWA sì ru sí àwọn ọmọ Israẹli;

22 nítorí pé wọn kò gba Ọlọrun gbọ́; wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé agbára ìgbàlà rẹ̀.

23 Sibẹ ó pàṣẹ fún ìkùukùu lókè, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀.

24 Ó rọ òjò mana sílẹ̀ fún wọn láti jẹ, ó sì fún wọn ní ọkà ọ̀run.

25 Ọmọ eniyan jẹ lára oúnjẹ àwọn angẹli; Ọlọrun fún wọn ní oúnjẹ àjẹtẹ́rùn.

26 Ó mú kí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn fẹ́ ní ojú ọ̀run, ó sì fi agbára rẹ̀ darí afẹ́fẹ́ ìhà gúsù;

27 ó sì rọ̀jò ẹran sílẹ̀ fún wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀; àní, ẹyẹ abìyẹ́ bíi yanrìn etí òkun.

28 Ó mú kí wọn bọ́ sílẹ̀ láàrin ibùdó; yíká gbogbo àgọ́ wọn,

29 Àwọn eniyan náà jẹ, wọ́n sì yó; nítorí pé Ọlọrun fún wọn ní ohun tí ọkàn wọn fẹ́.

30 Ṣugbọn kí wọn tó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn wọn lọ́rùn, àní, nígbà tí wọn ṣì ń jẹun lọ́wọ́.

31 Ọlọrun bínú sí wọn; ó pa àwọn tí ó lágbára jùlọ ninu wọn, ó sì lu àṣàyàn àwọn ọdọmọkunrin Israẹli pa.

32 Sibẹsibẹ wọ́n tún dẹ́ṣẹ̀; pẹlu gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọn kò gbàgbọ́.

33 Nítorí náà ó mú kí ọjọ́ ayé wọn pòórá bí afẹ́fẹ́; wọ́n sì lo ọjọ́ ayé wọn pẹlu ìjayà.

34 Nígbàkúùgbà tí ó bá ń pa wọ́n, wọn á wá a; wọn á ronupiwada, wọn á sì wá Ọlọrun tọkàntọkàn.

35 Wọn á ranti pé Ọlọrun ni àpáta ààbò wọn, ati pé Ọ̀gá Ògo ni olùràpadà wọn.

36 Ṣugbọn wọn kàn ń fi ẹnu wọn pọ́n ọn ni; irọ́ ni wọ́n sì ń pa fún un.

37 Ọkàn wọn kò dúró ṣinṣin lọ́dọ̀ rẹ̀; wọn kò sì pa majẹmu rẹ̀ mọ́.

38 Sibẹ, nítorí pé aláàánú ni, ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n, kò sì pa wọ́n run; ní ọ̀pọ̀ ìgbà ni ó dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró, tí kò sì fi gbogbo ara bínú sí wọn.

39 Ó ranti pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ lásán tí ń fẹ́ kọjá lọ, tí kò sì ní pada mọ́.

40 Ìgbà mélòó ni wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i ninu ijù, tí wọ́n sì bà á lọ́kàn jẹ́ ninu aṣálẹ̀!

41 Wọ́n dán an wò léraléra, wọ́n sì mú Ẹni Mímọ́ Israẹli bínú.

42 Wọn kò ranti agbára rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ranti ọjọ́ tí ó rà wọ́n pada lọ́wọ́ ọ̀tá;

43 nígbà tí ó ṣe iṣẹ́ abàmì ní ilẹ̀ Ijipti, tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní oko Soani.

44 Ó sọ omi odò wọn di ẹ̀jẹ̀, tí wọn kò fi lè mu omi wọn.

45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin sí wọn tí ó jẹ wọ́n, ati ọ̀pọ̀lọ́ tí ó pa wọ́n run.

46 Ó mú kí kòkòrò jẹ èso ilẹ̀ wọn; eṣú sì jẹ ohun ọ̀gbìn wọn.

47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́; ó sì fi òjò dídì run igi Sikamore wọn.

48 Ó fi yìnyín pa mààlúù wọn; ó sì sán ààrá pa agbo aguntan wọn.

49 Ó tú ibinu gbígbóná rẹ̀ lé wọn lórí: ìrúnú, ìkannú, ati ìpọ́njú, wọ́n dàbí ikọ̀ ìparun.

50 Ó fi àyè gba ibinu rẹ̀; kò dá ẹ̀mí wọn sí, ó sì fi àjàkálẹ̀ àrùn pa wọ́n.

51 O kọlu gbogbo àkọ́bí wọn ní ilẹ̀ Ijipti, àní, gbogbo àrẹ̀mọ ninu àgọ́ àwọn ọmọ Hamu.

52 Lẹ́yìn náà, ó kó àwọn eniyan rẹ̀ jáde bí agbo ẹran ó sì dà wọ́n láàrin aṣálẹ̀ bí agbo aguntan.

53 Ó dà wọ́n lọ láìléwu, ẹ̀rù kò bà wọ́n; òkun sì bo àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀.

54 Ó kó wọn wá sí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀, sí orí òkè tí ó ti fi agbára rẹ̀ gbà.

55 Ó lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde kí wọn ó tó dé ibẹ̀; ó pín ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn bí ohun ìní; ó sì fi àwọn ọmọ Israẹli jókòó ninu àgọ́ wọn.

56 Sibẹ, wọ́n dán Ọ̀gá Ògo wò, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí i; wọn kò tẹ̀lé ìlànà rẹ̀.

57 Wọ́n yipada, wọ́n sì hu ìwà ọ̀dàlẹ̀ bíi ti àwọn baba ńlá wọn; wọn kò ṣe é gbẹ́kẹ̀lé, wọ́n dàbí ọfà tí ó tẹ̀.

58 Wọ́n fi ojúbọ àwọn oriṣa wọn bí i ninu; wọ́n sì fi ère wọn mú un jowú.

59 Nígbà tí Ọlọrun gbọ́, inú bí i gidigidi; ó sì kọ Israẹli sílẹ̀ patapata.

60 Ó kọ ibùgbé rẹ̀ ní Ṣilo sílẹ̀, àní, àgọ́ rẹ̀ láàrin ọmọ eniyan.

61 Ó jẹ́ kí á gbé àmì agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn; ó sì fi ògo rẹ̀ lé ọ̀tá lọ́wọ́.

62 Ó jẹ́ kí á fi idà pa àwọn eniyan rẹ̀; ó sì bínú gidigidi sí àwọn eniyan ìní rẹ̀.

63 Iná run àwọn ọdọmọkunrin wọn; àwọn ọdọmọbinrin wọn kò sì rójú kọrin igbeyawo.

64 Àwọn alufaa kú ikú ogun; àwọn opó wọn kò sì rójú sọkún.

65 Lẹ́yìn náà, OLUWA dìde bí ẹni tají lójú oorun, bí ọkunrin alágbára tí ó mu ọtí yó tí ó ń kígbe.

66 Ó lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ sẹ́yìn; ó dójú tì wọ́n títí ayé.

67 Ó kọ àgọ́ àwọn ọmọ Josẹfu sílẹ̀; kò sì yan ẹ̀yà Efuraimu;

68 ṣugbọn ó yan ẹ̀yà Juda, ó sì yan òkè Sioni tí ó fẹ́ràn.

69 Níbẹ̀ ni ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀ tí ó ga bí ọ̀run sí, ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ bí ayé títí lae.

70 Ó yan Dafidi iranṣẹ rẹ̀; ó sì mú un láti inú agbo ẹran.

71 Ó mú un níbi tí ó ti ń tọ́jú àwọn aguntan tí ó lọ́mọ lẹ́yìn, kí ó lè máa tọ́jú àwọn ọmọ Jakọbu, eniyan rẹ̀, àní àwọn ọmọ Israẹli, eniyan ìní rẹ̀.

72 Ó tọ́jú wọn pẹlu òdodo, ó sì tọ́ wọn pẹlu ìmọ̀.

79

1 Ọlọrun, àwọn orílẹ̀-èdè abọ̀rìṣà ti wọ inú ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba ilé mímọ́ rẹ jẹ́; wọ́n sì ti sọ Jerusalẹmu di ahoro.

2 Wọ́n ti fi òkú àwọn iranṣẹ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ; wọ́n sì ti sọ òkú àwọn eniyan mímọ́ rẹ di ìjẹ fún àwọn ẹranko ìgbẹ́.

3 Wọ́n ti da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ bí omi, káàkiri Jerusalẹmu; kò sì sí ẹni tí yóo gbé wọn sin.

4 A ti di ẹni ẹ̀gàn lójú àwọn aládùúgbò wa; àwọn tí ó yí wa ká ń fi wá ṣe yẹ̀yẹ́; wọ́n sì ń fi wá rẹ́rìn-ín.

5 Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA? Ṣé títí ayé ni o óo máa bínú ni? Àbí owú rẹ yóo máa jó bí iná?

6 Tú ibinu rẹ sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́, ati orí àwọn ìjọba tí kò sìn ọ́.

7 Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run; wọ́n sì ti sọ ibùgbé rẹ di ahoro.

8 Má gbẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wa lára wa; yára, kí o ṣàánú wa, nítorí pé a ti rẹ̀ wá sílẹ̀ patapata.

9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọrun Olùgbàlà wa, nítorí iyì orúkọ rẹ; gbà wá, sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá, nítorí orúkọ rẹ.

10 Kí ló dé tí àwọn orílẹ̀-èdè yóo fi máa sọ pé, “Níbo ni Ọlọrun wọn wà?” Níṣojú wa, gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn iranṣẹ rẹ tí a pa lára àwọn orílẹ̀-èdè!

11 Jẹ́ kí ìkérora àwọn ìgbèkùn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ; gẹ́gẹ́ bí agbára ńlá rẹ, dá àwọn tí a dájọ́ ikú fún sí.

12 OLUWA, san ẹ̀san ẹ̀gàn tí àwọn aládùúgbò wa gàn ọ́, san án fún wọn ní ìlọ́po meje,

13 Nígbà náà, àwa eniyan rẹ, àní, àwa agbo aguntan pápá rẹ, yóo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ títí lae; a óo sì máa sọ̀rọ̀ ìyìn rẹ láti ìran dé ìran.

80

1 Dẹtí sílẹ̀, ìwọ olùṣọ́-aguntan Israẹli, Ìwọ tí ò ń tọ́jú àwọn ọmọ Josẹfu bí agbo ẹran. Ìwọ tí o gúnwà láàrin àwọn kerubu, yọ bí ọjọ́

2 níwájú Efuraimu ati Bẹnjamini ati Manase. Sọ agbára rẹ jí, kí o sì wá gbà wá là.

3 Mú wa bọ̀ sípò, Ọlọrun; fi ojurere wò wá, kí á le gbà wá là.

4 OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, yóo ti pẹ́ tó, tí o óo máa bínú sí adura àwọn eniyan rẹ?

5 O ti fi omijé bọ́ wọn bí oúnjẹ, o sì ti fún wọn ní omijé mu ní àmuyó.

6 O ti mú kí àwọn aládùúgbò wa máa jìjàdù lórí wa; àwọn ọ̀tá wa sì ń fi wá rẹ́rìn-ín láàrin ara wọn.

7 Mú wa bọ̀ sípò, Ọlọrun àwọn ọmọ ogun; fi ojurere wò wá, kí á lè là.

8 O mú ìtàkùn àjàrà kan jáde láti Ijipti; o lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde, o sì gbìn ín.

9 O ro ilẹ̀ fún un; ó ta gbòǹgbò wọlẹ̀, igi rẹ̀ sì gbilẹ̀.

10 Òjìji rẹ̀ bo àwọn òkè mọ́lẹ̀, ẹ̀ka rẹ sì bo àwọn igi kedari ńláńlá;

11 àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tàn kálẹ̀ títí kan òkun, àwọn èèhù rẹ̀ sì kan odò ńlá.

12 Kí ló dé tí o fi wó ògiri ọgbà rẹ̀, tí gbogbo àwọn tí ń kọjá lọ sì fi ń ká èso rẹ̀?

13 Àwọn ìmàdò inú ìgbẹ́ ń jẹ ẹ́ ní àjẹrun, gbogbo àwọn nǹkan tí ń káàkiri ninu oko sì ń jẹ ẹ́.

14 Jọ̀wọ́ tún yipada, Ọlọrun àwọn ọmọ ogun! Bojúwolẹ̀ láti ọ̀run, kí o sì wò ó; kí o sì tọ́jú ìtàkùn àjàrà yìí,

15 ohun ọ̀gbìn tí o fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbìn, àní, ọ̀dọ́ igi tí o fi ọwọ́ ara rẹ tọ́jú.

16 Àwọn ọ̀tá ti dáná sun ún, wọ́n ti gé e lulẹ̀; fi ojú burúkú wò wọ́n, kí wọ́n ṣègbé!

17 Ṣugbọn di ẹni tí o fúnra rẹ yàn mú, àní, ọmọ eniyan, tí o fúnra rẹ sọ di alágbára.

18 Ṣe bẹ́ẹ̀, a kò sì ní pada lẹ́yìn rẹ; dá wa sí, a ó sì máa sìn ọ́!

19 Mú wa bọ̀ sípò, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun! Fi ojurere wò wá, kí á lè là!

81

1 Ẹ kọ orin sókè sí Ọlọrun, agbára wa; ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọrun Jakọbu.

2 Ẹ dárin, ẹ lu samba, ẹ ta hapu dídùn ati lire.

3 Ẹ fọn fèrè ní ọjọ́ oṣù titun, ati ní ọjọ́ oṣù tí a yà sọ́tọ̀, ati ní ọjọ́ àsè.

4 Nítorí pé àṣẹ ni, fún àwọn ọmọ Israẹli, ìlànà sì ni, láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun Jakọbu.

5 Ó pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Josẹfu, nígbà tí ó kọlu ilẹ̀ Ijipti. Mo gbọ́ ohùn kan tí n kò gbọ́ rí: tí ó wí pé,

6 “Mo ti sọ àjàgà náà kalẹ̀ lọ́rùn rẹ; mo ti gba agbọ̀n ẹrù kúrò lọ́wọ́ rẹ.

7 Ninu ìnira, o ké pè mí, mo sì gbà ọ́; mo dá ọ lóhùn ninu ìjì ààrá, níbi tí mo fara pamọ́ sí; mo sì dán ọ wò ninu omi odò Meriba.

8 Ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan mi, nígbà tí mo bá ń kìlọ̀ fun yín, àní kí ẹ fetí sílẹ̀ sí mi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli!

9 Kò gbọdọ̀ sí ọlọrun àjèjì kan kan láàrin yín; ẹ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún oriṣa-koriṣa kan.

10 Èmi ni OLUWA Ọlọrun yín, tí ó mu yín jáde láti ilẹ̀ Ijipti. Ẹ ya ẹnu yín dáradára, n óo sì bọ yín ní àbọ́yó.

11 “Ṣugbọn àwọn eniyan mi kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, Israẹli kò sì gba tèmi.

12 Nítorí náà mo fi wọ́n sílẹ̀ sinu agídí ọkàn wọn, kí wọn máa ṣe ohun tó wù wọ́n.

13 Àwọn eniyan mi ìbá jẹ́ gbọ́ tèmi, àní Israẹli ìbá jẹ́ máa rìn ní ọ̀nà mi!

14 Kíákíá ni èmi ìbá kọjú ìjà sí àwọn ọ̀tá wọn, tí ǹ bá sì ṣẹgun wọn.

15 Àwọn tí ó kórìíra OLUWA yóo fi ìbẹ̀rùbojo tẹríba fún un, ìyà óo sì jẹ wọ́n títí lae.

16 Ṣugbọn èmi ó máa fi ọkà tí ó dára jùlọ bọ yín, n óo sì fi oyin inú àpáta tẹ yín lọ́rùn.”

82

1 Ọlọrun ti jókòó ní ààyè rẹ̀ ninu ìgbìmọ̀ ọ̀run; ó sì ń ṣe ìdájọ́ láàrin àwọn ẹ̀dá ọ̀run:

2 “Yóo ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin óo máa fi aiṣododo ṣe ìdájọ́, tí ẹ óo sì máa ṣe ojuṣaaju fún àwọn eniyan burúkú?

3 Ẹ ṣe ìdájọ́ òdodo fún àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn ọmọ aláìníbaba; ẹ sì máa ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tí ojú ń pọ́n ati àwọn talaka.

4 Ẹ gba talaka ati aláìní sílẹ̀, ẹ gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.”

5 Wọn kò ní ìmọ̀ tabi òye, wọ́n ń rìn kiri ninu òkùnkùn, títí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé fi mì tìtì.

6 Mo ní, “oriṣa ni yín, gbogbo yín ni ọmọ Ọ̀gá Ògo.

7 Ṣugbọn sibẹsibẹ, ẹ óo kú bí eniyan, ẹ ó sùn bí èyíkéyìí ninu àwọn ìjòyè.”

8 Dìde, Ọlọrun, ṣe ìdájọ́ ayé, nítorí tìrẹ ni gbogbo orílẹ̀-èdè!

83

1 Ọlọrun, má dákẹ́; má wòran; Ọlọrun má dúró jẹ́ẹ́!

2 Wò ó! Àwọn ọ̀tá rẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; àwọn tí ó kórìíra rẹ sì ń yájú sí ọ.

3 Wọ́n pète àrékérekè sí àwọn eniyan rẹ; wọ́n sì gbìmọ̀ pọ̀ sí àwọn tí ó sá di ọ́.

4 Wọ́n ní, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á pa orílẹ̀-èdè wọn run; kí á má ranti orúkọ Israẹli mọ́!”

5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ pète pèrò; wọ́n dá majẹmu láti dojú kọ ọ́.

6 Àwọn ará Edomu, ati àwọn ọmọ Iṣimaeli, àwọn ará Moabu, ati àwọn ọmọ Hagiri,

7 àwọn ará Gebali, àwọn ọmọ Amoni, ati àwọn ọmọ Amaleki, àwọn ará Filistia ati àwọn tí ń gbé Tire.

8 Àwọn ará Asiria pàápàá ti dara pọ̀ mọ́ wọn; àwọn ni alátìlẹ́yìn àwọn ọmọ Lọti.

9 Ṣe wọ́n bí o ti ṣe àwọn ará Midiani, bí o ti ṣe Sisera ati Jabini ni odò Kiṣoni,

10 àwọn tí o parun ní Endori, tí wọ́n di ààtàn lórí ilẹ̀.

11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí o ti ṣe Orebu ati Seebu; ṣe àwọn ìjòyè wọn bí o ti ṣe Seba ati Salumuna,

12 àwọn tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á mú lára ilẹ̀ Ọlọrun kí á sọ ọ́ di tiwa.”

13 Ọlọrun mi, ṣe wọ́n bí ààjà tíí ṣe ewé, àní, bí afẹ́fẹ́ tíí ṣe fùlùfúlù.

14 Bí iná tíí jó igbó, àní, bí ọwọ́ iná sì ṣe ń jó òkè kanlẹ̀,

15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ìjì rẹ lé wọn, kí o sì fi ààjà rẹ dẹ́rù bà wọ́n.

16 Da ìtìjú bò wọ́n, kí wọn lè máa wá ọ kiri, OLUWA.

17 Jẹ́ kí ojú tì wọ́n, kí ìdààmú dé bá wọn títí lae, kí wọn sì ṣègbé ninu ìtìjú.

18 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ nìkan, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA, ni Ọ̀gá Ògo lórí gbogbo ayé.

84

1 Ibùgbé rẹ lẹ́wà pupọ, OLUWA àwọn ọmọ ogun,

2 ọkàn àgbàlá tẹmpili OLUWA ń fà mí, àárò rẹ̀ ń sọ mí; tọkàn-tara ni mo fi ń kọrin ayọ̀ sí Ọlọrun alààyè.

3 Àwọn ẹyẹ ológoṣẹ́ pàápàá a máa kọ́ ilé, àwọn alápàáǹdẹ̀dẹ̀ a sì máa tẹ́ ìtẹ́ níbi tí wọ́n ń pa ọmọ sí, lẹ́bàá pẹpẹ rẹ, àní lẹ́bàá pẹpẹ rẹ, OLUWA àwọn ọmọ ogun, ọba mi, ati Ọlọrun mi.

4 Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń gbé inú ilé rẹ, wọn óo máa kọ orin ìyìn sí ọ títí lae!

5 Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo àwọn tí ó fi ọ́ ṣe agbára wọn, tí ìrìn àjò sí Sioni jẹ wọ́n lógún.

6 Bí wọ́n ti ń la àfonífojì Baka lọ, wọ́n ń sọ ọ́ di orísun omi; àkọ́rọ̀ òjò sì mú kí adágún omi kún ibẹ̀.

7 Wọn ó máa ní agbára kún agbára, títí wọn ó fi farahàn níwájú Ọlọrun ní Sioni.

8 OLUWA, Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, gbọ́ adura mi; tẹ́tí sílẹ̀, Ọlọrun Jakọbu!

9 Bojú wo àpáta wa, Ọlọrun, fi ojú àánú wo ẹni àmì òróró rẹ.

10 Nítorí pé ọjọ́ kan péré ninu àgbàlá rẹ, ṣe anfaani ju ẹgbẹrun ọjọ́ níbòmíràn lọ. Ó wù mí kí n jẹ́ aṣọ́nà ninu ilé Ọlọrun mi ju pé kí n máa gbé inú àgọ́ àwọn eniyan burúkú.

11 Nítorí OLUWA Ọlọrun ni oòrùn ati ààbò wa, òun níí ṣeni lóore, tíí dáni lọ́lá, nítorí OLUWA kò ní rowọ́ láti fún ẹni tí ọkàn rẹ̀ mọ́ ní ohun tí ó dára.

12 OLUWA àwọn ọmọ ogun, ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọ.

85

1 OLUWA, o fi ojurere wo ilẹ̀ rẹ; o dá ire Jakọbu pada.

2 O dárí àìdára àwọn eniyan rẹ jì wọ́n; o sì bo gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.

3 O mú ìrúnú rẹ kúrò; o dáwọ́ ibinu gbígbóná rẹ dúró.

4 Tún mú wa bọ̀ sípò, Ọlọrun Olùgbàlà wa; dáwọ́ inú tí ń bí ọ sí wa dúró.

5 Ṣé o óo máa bínú sí wa títí lae ni? Ṣé ibinu rẹ yóo máa tẹ̀síwájú láti ìran dé ìran ni?

6 Ṣé o ò ní tún sọ wá jí ni, kí àwọn eniyan rẹ lè máa yọ̀ ninu rẹ?

7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn wá, OLUWA; kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.

8 Jẹ́ kí n gbọ́ ohun tí Ọlọrun, OLUWA yóo wí, nítorí pé ọ̀rọ̀ alaafia ni yóo sọ fún àwọn eniyan rẹ̀, àní, àwọn olùfọkànsìn rẹ̀, ṣugbọn kí wọn má yipada sí ìwà òmùgọ̀.

9 Nítòótọ́, ìgbàlà rẹ̀ wà nítòsí fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀; kí ògo rẹ̀ lè wà ní ilẹ̀ wa.

10 Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ yóo pàdé; òdodo ati alaafia yóo dì mọ́ ara wọn.

11 Òtítọ́ yóo rú jáde láti inú ilẹ̀; òdodo yóo sì bojú wolẹ̀ láti ojú ọ̀run.

12 Dájúdájú, OLUWA yóo fúnni ní ohun tí ó dára; ilẹ̀ wa yóo sì mú èso jáde lọpọlọpọ.

13 Òdodo yóo máa rìn lọ níwájú rẹ̀, yóo sì sọ ipasẹ̀ rẹ̀ di ọ̀nà.

86

1 Tẹ́tí sí mi OLUWA, kí o sì gbọ́ adura mi, nítorí òtòṣì ati aláìní ni mí.

2 Dá ẹ̀mí mi sí nítorí olùfọkànsìn ni mí; gba èmi iranṣẹ rẹ tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là; ìwọ ni Ọlọrun mi.

3 Ṣàánú mi, OLUWA, nítorí ìwọ ni mò ń kígbe pè tọ̀sán-tòru.

4 Mú inú iranṣẹ rẹ dùn, nítorí ìwọ ni mò ń gbadura sí.

5 Nítorí pé olóore ni ọ́, OLUWA, o máa ń dárí jini; ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀ sí gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.

6 Fetí sí adura mi, OLUWA, gbọ́ igbe ẹ̀bẹ̀ mi.

7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mo ké pè ọ́, nítorí pé o máa ń gbọ́ adura mi.

8 OLUWA, kò sí èyí tí ó dàbí rẹ ninu àwọn oriṣa; kò sì sí iṣẹ́ ẹni tí ó dàbí iṣẹ́ rẹ.

9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí o dá ni yóo wá, OLUWA, wọn óo máa forí balẹ̀ níwájú rẹ: wọn óo sì máa yin orúkọ rẹ lógo.

10 Nítorí pé o tóbi, o sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọrun.

11 OLUWA, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, kí n lè máa rìn ninu òtítọ́ rẹ; kí n lè pa ọkàn pọ̀ láti máa bẹ̀rù orúkọ rẹ.

12 Gbogbo ọkàn ni mo fi dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, OLUWA, Ọlọrun mi; n óo máa yin orúkọ rẹ lógo títí lae.

13 Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi sí mi; o ti yọ ọkàn mi kúrò ninu isà òkú.

14 Ọlọrun, àwọn agbéraga dìde sí mi; ẹgbẹ́ àwọn ìkà, aláìláàánú kan ń lépa ẹ̀mí mi; wọn kò sì bìkítà fún ọ.

15 Ṣugbọn ìwọ, OLUWA, ni Ọlọrun aláàánú ati olóore; o kì í tètè bínú, o sì kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀, ati òtítọ́.

16 Kọjú sí mi, kí o sì ṣàánú mi; fún èmi iranṣẹ rẹ ní agbára rẹ; kí o sì gba èmi ọmọ iranṣẹbinrin rẹ là.

17 Fi àmì ojurere rẹ hàn mí, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè rí i, kí ojú sì tì wọ́n; nítorí pé ìwọ, OLUWA, ni o ràn mí lọ́wọ́, tí o sì tù mí ninu.

87

1 Ní orí òkè mímọ́ ni ìlú tí OLUWA tẹ̀dó wà.

2 OLUWA fẹ́ràn ẹnubodè Sioni ju gbogbo ìlú yòókù lọ ní ilẹ̀ Jakọbu.

3 Ọpọlọpọ nǹkan tó lógo ni a sọ nípa rẹ, ìwọ ìlú Ọlọrun.

4 Tí mo bá ń ka àwọn ilẹ̀ tí ó mọ rírì mi, n óo dárúkọ Ijipti ati Babiloni, Filistia ati Tire, ati Etiopia. Wọn á máa wí pé, “Ní Jerusalẹmu ni wọ́n ti bí eléyìí.”

5 A óo wí nípa Sioni pé, “Ibẹ̀ ni a ti bí eléyìí ati onítọ̀hún,” nítorí pé Ọ̀gá Ògo yóo fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.

6 OLUWA yóo ṣírò rẹ̀ mọ́ wọn nígbà tí ó bá ń ṣe àkọsílẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ pé, “Ní Sioni ni a ti bí eléyìí.”

7 Àwọn akọrin ati àwọn afunfèrè ati àwọn tí ń jó yóo máa sọ pé, “Ìwọ, Sioni, ni orísun gbogbo ire wa.”

88

1 OLUWA, Ọlọrun, Olùgbàlà mi, mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́ ní ọ̀sán; mo ké níwájú rẹ ní òru.

2 Jẹ́ kí adura mi dé ọ̀dọ̀ rẹ; tẹ́tí sí igbe mi.

3 Nítorí pé ọkàn mi kún fún ìyọnu; mo sì súnmọ́ isà òkú.

4 Mo dàbí àwọn tí ó ń wọ ibojì lọ; mo dà bí ẹni tí kò lágbára mọ.

5 N kò yàtọ̀ sí ẹni tí a pa tì sí apá kan láàrin àwọn òkú, mo dàbí ẹni tí a pa, tí ó sùn ninu ibojì, bí àwọn tí ìwọ kò ranti mọ́, nítorí pé wọ́n ti kúrò lábẹ́ ìtọ́jú rẹ.

6 O ti fi mí sinu isà òkú tí ó jìn pupọ, ninu òkùnkùn, àní ninu ọ̀gbun.

7 Ọwọ́ ibinu rẹ wúwo lára mi, ìgbì ìrúnú rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.

8 O ti mú kí àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi fi mí sílẹ̀; mo sì ti di ẹni ìríra lọ́dọ̀ wọn: mo wà ninu àhámọ́, n kò sì lè jáde;

9 ojú mi ti di bàìbàì nítorí ìbànújẹ́. Lojoojumọ ni mò ń ké pè ọ́, OLUWA; tí mò ń tẹ́wọ́ adura sí ọ.

10 Ṣé òkú ni o óo ṣe iṣẹ́ ìyanu hàn? Ṣé àwọn òkú lè dìde kí wọ́n máa yìn ọ́?

11 Ṣé a lè sọ̀rọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ninu ibojì? Àbí ẹnìkan lè sọ̀rọ̀ òtítọ́ rẹ ninu ìparun?

12 Ṣé a lè rí iṣẹ́ ìyanu rẹ ninu òkùnkùn ikú? Àbí ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà rẹ wà ní ilẹ̀ àwọn tí a ti gbàgbé?

13 Ṣugbọn OLUWA, èmi ń ké pè ọ́; ní òwúrọ̀ n óo gbadura sí ọ.

14 OLUWA, kí ló dé tí o fi ta mí nù? Kí ló dé tí o fi ojú pamọ́ fún mi?

15 Láti ìgbà èwe mi ni a tí ń jẹ mí níyà, tí mo sì fẹ́rẹ̀ kú, mo ti rí ìjẹníyà rẹ tí ó bani lẹ́rù; agara sì ti dá mi.

16 Ìrúnú rẹ bò mí mọ́lẹ̀; ẹ̀rù rẹ sì bà mí dójú ikú.

17 Wọ́n yí mi ká tọ̀sán-tòru bí ìṣàn omi ńlá; wọ́n ká mi mọ́ patapata.

18 O ti mú kí ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi ati àwọn alábàárìn mi kọ̀ mí sílẹ̀; òkùnkùn nìkan ni ó yí mi ká níbi gbogbo.

89

1 OLUWA, n óo máa kọrin ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ títí lae; n óo máa fi ẹnu mi kéde òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.

2 Nítorí pé, a ti fi ìdí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ múlẹ̀ títí lae; o sì ti fi ìdí òtítọ́ rẹ múlẹ̀ bí ojú ọ̀run.

3 O sọ pé, “Mo ti dá majẹmu kan pẹlu ẹni tí mo yàn, mo ti búra fún Dafidi, iranṣẹ mi, pé,

4 ‘N óo fi ìdí àwọn ọmọ rẹ múlẹ̀ títí lae, n óo sì gbé ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

5 Jẹ́ kí ojú ọ̀run máa kọrin ìyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ, OLÚWA; kí àwọn eniyan mímọ́ sì máa kọrin ìyìn òtítọ́ rẹ.

6 Nítorí ta ni a lè fi wé ọ ní ọ̀run, OLUWA? Ta ni ó dàbí OLUWA láàrin àwọn ẹ̀dá ọ̀run?

7 Ọlọrun, ìwọ ni a bẹ̀rù ninu ìgbìmọ̀ àwọn eniyan mímọ́, o tóbi, o sì lẹ́rù ju gbogbo àwọn tí ó yí ọ ká lọ?

8 OLUWA, Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, ta ló lágbára bíi rẹ? OLUWA, òtítọ́ rẹ yí ọ ká.

9 Ò ń jọba lórí òkun tí ń ru; nígbà tí ìgbì rẹ̀ bá ru sókè, ìwọ ni ò ń mú kí ó rọlẹ̀.

10 Ìwọ ni o wó Rahabu mọ́lẹ̀ bí òkú ẹran; o fi ọwọ́ agbára rẹ fọ́n àwọn ọ̀tá rẹ ká.

11 Tìrẹ ni ọ̀run, tìrẹ sì ni ayé pẹlu; ìwọ ni o tẹ ayé ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀ dó.

12 Ìwọ ni o dá àríwá ati gúsù, òkè Tabori ati òkè Herimoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.

13 Alágbára ni ọ́; agbára ń bẹ ní ọwọ́ rẹ; o gbé ọwọ́ agbára rẹ sókè.

14 Òdodo ati ẹ̀tọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ; ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ ń lọ ṣiwaju rẹ.

15 Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ó mọ ìhó ayọ̀ nnì, àwọn tí ń rìn ninu ìmọ́lẹ̀ ojurere rẹ, OLUWA,

16 àwọn tí ń yọ̀ nítorí orúkọ rẹ tọ̀sán-tòru, tí sì ń gbé òdodo rẹ lárugẹ.

17 Nítorí ìwọ ni ògo ati agbára wọn; nípa ojurere rẹ sì ni a ti ní ìṣẹ́gun.

18 Dájúdájú, OLUWA, tìrẹ ni ààbò wa; ìwọ, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ọba wa.

19 Ní ìgbàanì, o sọ ninu ìran fún olùfọkànsìn rẹ pé, “Mo ti fi adé dé alágbára kan lórí, mo ti gbé ẹnìkan ga tí a yàn láàrin àwọn eniyan.

20 Mo ti rí Dafidi, iranṣẹ mi; mo ti fi òróró mímọ́ mi yàn án;

21 kí ọwọ́ agbára mi lè máa gbé e ró títí lae, kí ọwọ́ mi sì máa fún un ní okun.

22 Ọ̀tá kan kò ní lè borí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn eniyan burúkú kò ní tẹ orí rẹ̀ ba.

23 N óo run ọ̀tá rẹ̀ níwájú rẹ̀; n óo sì bá àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ kanlẹ̀.

24 Òtítọ́ mi ati ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ yóo wà pẹlu rẹ̀; orúkọ mi ni yóo sì máa fi ṣẹgun.

25 N óo mú ìjọba rẹ̀ gbòòrò dé òkun; agbára rẹ̀ yóo sì tàn dé odò Yufurate

26 Yóo ké pè mí pé, ‘Ìwọ ni Baba mi, Ọlọrun mi, ati Àpáta ìgbàlà mi.’

27 N óo fi ṣe àkọ́bí, àní, ọba tí ó tóbi ju gbogbo ọba ayé lọ.

28 N óo máa fi ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ hàn án títí lae; majẹmu èmi pẹlu rẹ̀ yóo sì dúró ṣinṣin.

29 Arọmọdọmọ rẹ̀ ni yóo máa jọba títí lae; ìtẹ́ rẹ̀ yóo sì máa bẹ níwọ̀n ìgbà tí ojú ọ̀run bá ń bẹ.

30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀, tí wọn kò sì tẹ̀lé ìlànà mi,

31 bí wọ́n bá tàpá sí àṣẹ mi, tí wọn kò sì pa òfin mi mọ́;

32 n óo nà wọ́n lẹ́gba nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, n óo sì nà wọ́n ní pàṣán nítorí àìdára wọn.

33 Ṣugbọn ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ kò ní kúrò lára rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní yẹ òtítọ́ mi.

34 N kò ni yẹ majẹmu mi, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní yí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ pada.

35 “Níwọ̀n ìgbà tí mo ti fi ìwà mímọ́ mi búra: n kò ní purọ́ fún Dafidi.

36 Arọmọdọmọ rẹ̀ ni yóo máa jọba títí lae, ìtẹ́ rẹ̀ yóo sì máa wà níwájú mi, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn bá ń yọ.

37 A óo fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ bí òṣùpá títí lae, yóo dúró ṣinṣin níwọ̀n ìgbà tí ojú ọ̀run bá ń bẹ.”

38 Ṣugbọn nisinsinyii inú rẹ ti ru sí ẹni àmì òróró rẹ; o ti ta á nù, o sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

39 O ti pa majẹmu tí o bá iranṣẹ rẹ dá tì, o ti ba adé rẹ̀ jẹ́, o ti fi wọ́lẹ̀.

40 O ti wó gbogbo odi rẹ̀; o sì ti sọ ilé ìṣọ́ rẹ̀ di ahoro.

41 Gbogbo àwọn tí ń kọjá lọ ní ń kó o lẹ́rù; ó ti di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn aládùúgbò rẹ̀.

42 O ti ran àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́; o ti mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ yọ̀ ọ́.

43 Àní, o ti ba gbogbo ohun ìjà rẹ̀ jẹ́, o kò sì ràn án lọ́wọ́ lójú ogun.

44 O ti gba ọ̀pá àṣẹ lọ́wọ́ rẹ̀; o sì ti wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀.

45 O ti gé ìgbà èwe rẹ̀ kúrú; o sì ti da ìtìjú bò ó.

46 Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA? Ṣé títí lae ni o óo máa fi ara pamọ́ fún mi? Yóo ti pẹ́ tó tí ibinu rẹ yóo máa jò bí iná?

47 OLUWA, ranti bí ọjọ́ ayé ẹ̀dá ti gùn mọ, ati pé ẹ̀dá lásán ni ọmọ eniyan!

48 Ta ló wà láyé tí kò ní kú? Ta ló lè gba ẹ̀mí ara rẹ̀ lọ́wọ́ agbára isà òkú?

49 OLUWA, níbo ni ìfẹ́ rẹ ìgbàanì tí kì í yẹ̀ wà, tí o búra fún Dafidi pẹlu òtítọ́ rẹ?

50 OLUWA, ranti bí èmi, iranṣẹ rẹ, ti di ẹni yẹ̀yẹ́; ati bí mo ti ń farada ẹ̀gàn àwọn eniyan,

51 OLUWA àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ẹni tí o fi àmì òróró yàn ṣe yẹ̀yẹ́, wọ́n sì ń kẹ́gàn ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀.

52 Ẹni ìyìn ni OLUWA títí lae! Amin! Amin!

90

1 OLUWA, ìwọ ni o ti jẹ́ ibi ààbò wa láti ìrandíran.

2 Kí o tó dá àwọn òkè, ati kí o tó dá ilẹ̀ ati ayé, láti ayérayé, ìwọ ni Ọlọrun.

3 O sọ eniyan di erùpẹ̀ pada, o sì wí pé, “Ẹ yipada, ẹ̀yin ọmọ eniyan.”

4 Nítorí pé lójú rẹ, ẹgbẹrun ọdún dàbí àná, tabi bí ìṣọ́ kan ní òru.

5 Ìwọ a máa gbá ọmọ eniyan dànù; wọ́n dàbí àlá, bíi koríko tí ó tutù ní òwúrọ̀;

6 ní òwúrọ̀ á máa gbilẹ̀, á sì máa jí pérépéré; ní ìrọ̀lẹ́ á sá, á sì rọ.

7 Ibinu rẹ pa wá run; ìrúnú rẹ sì bò wá mọ́lẹ̀.

8 O ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa kalẹ̀ ní iwájú rẹ; àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìkọ̀kọ̀ wa sì hàn kedere ninu ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.

9 Nítorí ọjọ́ ayé wa ń kọjá lọ ninu ibinu rẹ; ayé wa sì ń dópin bí ẹni mí kanlẹ̀.

10 Aadọrin ọdún ni ọjọ́ ayé wa; pẹlu ipá a lè tó ọgọrin; sibẹ gbogbo rẹ̀ jẹ́ kìkì làálàá ati ìyọnu; kíá, ayé wa á ti dópin, ẹ̀mí wa á sì fò lọ.

11 Ta ló mọ agbára ibinu rẹ? Ta ló sì mọ̀ pé bí ẹ̀rù rẹ ti tó bẹ́ẹ̀ ni ibinu rẹ rí?

12 Nítorí náà kọ́ wa láti máa ka iye ọjọ́ orí wa, kí á lè kọ́gbọ́n.

13 Yipada sí wa, OLUWA; yóo ti pẹ́ tó tí o óo máa bínú sí wa? Ṣàánú àwa iranṣẹ rẹ.

14 Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀, kí á lè máa yọ̀, kí inú wa sì máa dùn ní gbogbo ọjọ́ ayé wa.

15 Mú inú wa dùn fún iye ọjọ́ tí o ti fi pọ́n wa lójú, ati fún iye ọdún tí ojú wa ti fi rí ibi.

16 Jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ hàn sí àwọn iranṣẹ rẹ, kí agbára rẹ tí ó lógo sì hàn sí àwọn ọmọ wọn.

17 Jẹ́ kí ojurere OLUWA Ọlọrun wa wà lára wa, fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀, jẹ́ kí iṣẹ́ ọwọ́ wa fi ìdí múlẹ̀.

91

1 Ẹni tí ń gbé abẹ́ ààbò Ọ̀gá Ògo, tí ó wà lábẹ́ òjìji Olodumare,

2 yóo wí fún OLUWA pé, “Ìwọ ni ààbò ati odi mi, Ọlọrun mi, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé.”

3 Nítorí yóo yọ ọ́ ninu okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ ati ninu àjàkálẹ̀ àrùn apanirun.

4 Yóo da ìyẹ́ rẹ̀ bò ọ́, lábẹ́ ìyẹ́ apá rẹ̀ ni o óo ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóo jẹ́ asà ati apata rẹ.

5 O ò ní bẹ̀rù ìdágìrì òru, tabi ọfà tí ń fò kiri ní ọ̀sán,

6 tabi àjàkálẹ̀ àrùn tí ń jà kiri ninu òkùnkùn, tabi ìparun tí ń ṣeni lófò ní ọ̀sán gangan.

7 Ẹgbẹrun lè ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, tabi ẹgbaarun ni apá ọ̀tún rẹ; ṣugbọn kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.

8 Ojú nìkan ni óo kàn máa fi rí wọn, tí o óo sì máa fi wo èrè àwọn eniyan burúkú.

9 Nítorí tí ìwọ ti fi OLUWA ṣe ààbò rẹ, o sì ti fi Ọ̀gá Ògo ṣe ibùgbé rẹ,

10 ibi kankan kò ní dé bá ọ, bẹ́ẹ̀ ni àjálù kankan kò ní súnmọ́ ilé rẹ.

11 Nítorí yóo pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀, nítorí rẹ, pé kí wọ́n máa pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ.

12 Wọ́n óo fi ọwọ́ wọn gbé ọ sókè, kí o má baà fi ẹsẹ̀ gbún òkúta.

13 O óo rìn kọjá lórí kinniun ati paramọ́lẹ̀; ẹgbọ̀rọ̀ kinniun ati ejò ńlá ni o óo fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.

14 OLUWA ní, “Nítorí pé ó nífẹ̀ẹ́ sí mi, n óo gbà á là; n óo dáàbò bò ó, nítorí pé ó mọ orúkọ mi.

15 Yóo pè mí, n óo sì dá a lóhùn; n óo wà pẹlu rẹ̀ ninu ìṣòro, n óo yọ ọ́ ninu rẹ̀, n óo dá a lọ́lá.

16 N óo fi ẹ̀mí gígùn tẹ́ ẹ lọ́rùn, n óo sì gbà á là.”

92

1 Ó dára kí eniyan máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, OLUWA; kí ó sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ, ìwọ Ọ̀gá Ògo;

2 ó dára kí eniyan máa kéde ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ní òwúrọ̀, kí ó máa kéde òtítọ́ rẹ ní alẹ́,

3 pẹlu orin, lórí ohun èlò orin olókùn mẹ́wàá, ati hapu.

4 Nítorí ìwọ, OLUWA, ti mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ; OLUWA, mò ń fi ayọ̀ kọrin nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

5 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ tóbi pupọ, OLÚWA! Èrò rẹ sì jinlẹ̀ pupọ!

6 Òpè eniyan kò lè mọ̀, kò sì le yé òmùgọ̀:

7 pé bí eniyan burúkú bá tilẹ̀ rú bíi koríko, tí gbogbo àwọn aṣebi sì ń gbilẹ̀, ó dájú pé ìparun ayérayé ni òpin wọn.

8 Ṣugbọn ẹni àgbéga títí lae ni ọ́, OLUWA.

9 Wò ó, OLUWA, àwọn ọ̀tá rẹ yóo parun; gbogbo àwọn aṣebi yóo sì fọ́n ká.

10 Ṣugbọn o ti gbé mi ga, o ti fún mi lágbára bíi ti ẹfọ̀n; o ti da òróró dáradára sí mi lórí.

11 Mo ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi, mo sì ti fi etí mi gbọ́ ìparun àwọn ẹni ibi tí ó gbé ìjà kò mí.

12 Àwọn olódodo yóo gbilẹ̀ bí igi ọ̀pẹ, wọn óo dàgbà bí igi kedari ti Lẹbanoni.

13 Wọ́n dàbí igi tí a gbìn sí ilé OLUWA, tí ó sì ń dàgbà ninu àgbàlá Ọlọrun wa.

14 Wọn á máa so èso títí di ọjọ́ ogbó wọn, wọn á máa lómi lára, ewé wọn á sì máa tutù nígbà gbogbo;

15 láti fihàn pé olóòótọ́ ni OLUWA; òun ni àpáta mi, kò sì sí aiṣododo lọ́wọ́ rẹ̀.

93

1 OLUWA jọba; ó gbé ọlá ńlá wọ̀ bí ẹ̀wù; OLUWA gbé ọlá ńlá wọ̀, ó sì di agbára ni àmùrè. Ó fi ìdí ayé múlẹ̀; kò sì ní yẹ̀ laelae.

2 A ti fi ìdí ìjọba rẹ múlẹ̀ láti ìgbà laelae; láti ayérayé ni o ti wà.

3 Ibú omi gbé ohùn wọn sókè, OLUWA, ibú omi gbé ohùn wọn sókè, ó sì ń sán bí ààrá.

4 OLUWA lágbára lókè! Ó lágbára ju ariwo omi òkun lọ, ó lágbára ju ìgbì omi òkun lọ.

5 Àwọn òfin rẹ kìí yipada, ìwà mímọ́ ni ó yẹ ilé rẹ títí lae, OLUWA.

94

1 OLUWA, ìwọ Ọlọrun ẹ̀san, ìwọ Ọlọrun ẹ̀san, fi agbára rẹ hàn!

2 Dìde, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san èrè iṣẹ́ àwọn agbéraga fún wọn!

3 OLUWA, yóo ti pẹ́ tó? Àní, yóo ti pẹ́ tó tí àwọn eniyan burúkú yóo máa ṣe jàgínní?

4 Wọ́n ń fi ìgbéraga sọ̀rọ̀ jàbùjàbù, gbogbo àwọn aṣebi ní ń fọ́nnu.

5 Wọ́n ń rún àwọn eniyan rẹ mọ́lẹ̀, OLUWA, wọ́n ń pọ́n àwọn eniyan rẹ lójú.

6 Wọ́n ń pa àwọn opó ati àwọn àlejò, wọ́n sì ń pa àwọn aláìníbaba;

7 wọ́n ń sọ pé, “OLUWA kò rí wa; Ọlọrun Jakọbu kò ṣàkíyèsí wa.”

8 Ẹ jẹ́ kí ó ye yín, ẹ̀yin tí ẹ ya òpè jùlọ láàrin àwọn eniyan! Ẹ̀yin òmùgọ̀, nígbà wo ni ẹ óo gbọ́n?

9 Ṣé ẹni tí ó dá etí, ni kò ní gbọ́ràn? Àbí ẹni tí ó dá ojú, ni kò ní ríran?

10 Ṣé ẹni tí ń jẹ àwọn orílẹ̀-èdè níyà, ni kò ní jẹ yín níyà? Àbí ẹni tí ń fún eniyan ní ìmọ̀, ni kò ní ní ìmọ̀?

11 OLUWA mọ èrò ọkàn ọmọ eniyan, ó mọ̀ pé afẹ́fẹ́ lásán ni.

12 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí o bá báwí, OLUWA, tí o sì kọ́ ní òfin rẹ,

13 kí ó lè sinmi lọ́wọ́ ọjọ́ ìṣòro, títí tí a ó fi gbẹ́ kòtò fún eniyan burúkú.

14 Nítorí OLUWA kò ní kọ àwọn eniyan rẹ̀ sílẹ̀; kò ní ṣá àwọn eniyan ìní rẹ̀ tì;

15 nítorí pé ìdájọ́ òtítọ́ yóo pada jẹ́ ìpín àwọn olódodo, àwọn olóòótọ́ yóo sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

16 Ta ni yóo bá mi dìde sí àwọn eniyan burúkú? Ta ni yóo bá mi dìde sí àwọn aṣebi?

17 Bí kì í bá ṣe pé OLUWA ràn mí lọ́wọ́, ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní isà òkú.

18 Nígbà tí mo rò pé, “Ẹsẹ̀ mi ti yọ̀,” OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni ó gbé mi ró.

19 Nígbà tí àìbàlẹ̀ ọkàn mi pọ̀ pupọ, ìwọ ni o tù mí ninu, tí o dá mi lọ́kàn le.

20 Ǹjẹ́ o lè ní àjọṣe pẹlu àwọn ìkà aláṣẹ, àwọn tí ń fi òfin gbé ìwà ìkà ró?

21 Wọ́n para pọ̀ láti gba ẹ̀mí olódodo; wọ́n sì dá ẹjọ́ ikú fún aláìṣẹ̀.

22 Ṣugbọn OLUWA ti di ibi ìsádi mi, Ọlọrun mi sì ti di àpáta ààbò mi.

23 Yóo san ẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn, yóo pa wọ́n run nítorí ìwà ìkà wọn. OLUWA Ọlọrun wa yóo pa wọ́n run.

95

1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á kọrin sí OLUWA; ẹ jẹ́ kí á hó ìhó ayọ̀ sí Olùdáàbòbò ati ìgbàlà wa!

2 Ẹ jẹ́ kí á wá siwaju rẹ̀ pẹlu ọpẹ́; ẹ jẹ́ kí á fi orin ìyìn hó ìhó ayọ̀ sí i.

3 Nítorí pé Ọlọrun tí ó tóbi ni OLUWA, ọba tí ó tóbi ni, ó ju gbogbo oriṣa lọ.

4 Ìkáwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà; gíga àwọn òkè ńlá wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pẹlu.

5 Tirẹ̀ ni òkun, nítorí pé òun ni ó dá a; ọwọ́ rẹ̀ ni ó sì fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.

6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á jọ́sìn, kí á tẹríba, ẹ jẹ́ kí á kúnlẹ̀ níwájú OLUWA, Ẹlẹ́dàá wa!

7 Nítorí òun ni Ọlọrun wa, àwa ni eniyan rẹ̀, tí ó ń kó jẹ̀ káàkiri, àwa ni agbo aguntan rẹ̀. Bí ẹ bá gbọ́ ohùn rẹ̀ lónìí,

8 ẹ má ṣe orí kunkun bí ẹ ti ṣe ní Meriba, ati bí ẹ ti ṣe ní ijọ́un ní Masa, ninu aṣálẹ̀

9 nígbà tí àwọn baba ńlá yín dán mi wò, tí wọ́n dẹ mí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti rí ohun tí mo ti ṣe rí.

10 Fún ogoji ọdún gbáko ni ọ̀rọ̀ wọn fi sú mi, tí mo sọ pé, “Ọkàn àwọn eniyan wọnyi ti yapa, wọn kò sì bìkítà fún ìlànà mi.”

11 Nítorí náà ni mo fi fi ibinu búra pé, wọn kò ní wọ inú ìsinmi mi.

96

1 Ẹ kọ orin titun sí OLUWA; gbogbo ayé, ẹ kọ orin sí OLUWA.

2 Ẹ kọ orin sí OLUWA, ẹ yin orúkọ rẹ̀; ẹ sọ nípa ìgbàlà rẹ̀ láti ọjọ́ dé ọjọ́.

3 Ẹ kéde ògo rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè; ẹ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrin àwọn eniyan.

4 Nítorí OLUWA tóbi, ó yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọ; ó sì yẹ kí á bẹ̀rù rẹ̀ ju gbogbo oriṣa lọ.

5 Nítorí oriṣa lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù ń sìn, ṣugbọn OLUWA ni ó dá ọ̀run.

6 Iyì ati ọlá ńlá ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀; agbára ati ẹwà kún inú ilé mímọ́ rẹ̀.

7 Ẹ yin OLUWA, gbogbo ẹ̀yin aráyé; ẹ kókìkí ògo ati agbára rẹ̀.

8 Ẹ fún OLUWA ní iyì tí ó tọ́ sí orúkọ rẹ̀, ẹ mú ọrẹ lọ́wọ́ wá sinu àgbàlá rẹ̀.

9 Ẹ sin OLUWA ninu ẹwà ìwà mímọ́; gbogbo ayé, ẹ wárìrì níwájú rẹ̀.

10 Ẹ wí láàrin àwọn orílẹ̀-èdè pé, “OLUWA jọba! A ti fi ìdí ayé múlẹ̀, kò sì ní yẹ̀ lae; OLUWA yóo fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.”

11 Jẹ́ kí inú ọ̀run ó dùn, sì jẹ́ kí ayé ó yọ̀; kí òkun ó hó, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀.

12 Jẹ́ kí pápá oko ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀ yọ̀. Nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóo fi ayọ̀ kọrin,

13 níwájú OLUWA, nítorí pé ó ń bọ̀; ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé; yóo sì fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.

97

1 OLUWA jọba, kí ayé ó yọ̀; jẹ́ kí inú ogunlọ́gọ̀ erékùṣù ó dùn.

2 Ìkùukùu ati òkùnkùn biribiri ni ó yí i ká; òdodo ati ẹ̀tọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ̀.

3 Iná ń jó lọ níwájú rẹ̀, ó sì ń jó àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́tùn-ún lósì.

4 Mànàmáná rẹ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí ayé, ilẹ̀ ayé rí i, ó sì wárìrì.

5 Àwọn òkè ńlá yọ́ bí ìda níwájú OLUWA, àní, níwájú OLUWA gbogbo ayé.

6 Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè sì ń wo ògo rẹ̀.

7 Ojú ti gbogbo àwọn tí ń bọ oriṣa, àwọn tí ń fi ère lásánlàsàn yangàn; gbogbo oriṣa ní ń foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀.

8 Àwọn ará Sioni gbọ́, inú wọn dùn. Àwọn ará ìlú Juda sì ń yọ̀, nítorí ìdájọ́ rẹ, OLUWA.

9 Nítorí ìwọ OLUWA ni Ọ̀gá Ògo, o ju gbogbo ayé lọ, a gbé ọ ga ju gbogbo oriṣa lọ.

10 Ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn OLUWA, ẹ kórìíra ibi; OLUWA á máa dá ẹ̀mí àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sí, a sì máa gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.

11 Ìmọ́lẹ̀ á máa tàn fún àwọn olódodo, ayọ̀ sì wà fún àwọn olótìítọ́ inú.

12 Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo, kí ẹ sì máa yin orúkọ mímọ́ rẹ̀.

98

1 Ẹ kọ orin titun sí OLUWA, nítorí tí ó ti ṣe ohun ìyanu; agbára ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ati apá mímọ́ rẹ̀ ni ó fi ṣẹgun.

2 OLUWA ti sọ ìṣẹ́gun rẹ̀ di mímọ̀, ó ti fi ìdáláre rẹ̀ hàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè.

3 Ó ranti ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, ati òtítọ́ rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli; gbogbo ayé ti rí ìṣẹ́gun Ọlọrun wa.

4 Gbogbo ayé, ẹ hó ìhó ayọ̀ sí OLUWA; ẹ bú sí orin ayọ̀, kí ẹ sì kọ orin ìyìn.

5 Ẹ fi hapu kọ orin ìyìn sí OLUWA, àní, hapu ati ohùn orin dídùn.

6 Ẹ fun fèrè ati ìwo kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀ níwájú OLUWA Ọba.

7 Kí òkun ó hó, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀, kí ayé hó, ati àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

8 Omi òkun, ẹ pàtẹ́wọ́; kí ẹ̀yin òkè sì fi ayọ̀ kọrin pọ̀

9 níwájú OLUWA, nítorí pé ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé; yóo sì fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.

99

1 OLUWA jọba, kí àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì; ó gúnwà lórí àwọn kerubu; kí ilẹ̀ mì tìtì.

2 OLUWA tóbi ní Sioni, ó sì jọba lórí gbogbo orílẹ̀-èdè.

3 Jẹ́ kí wọ́n yin orúkọ rẹ tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, mímọ́ ni OLUWA!

4 Ọba alágbára, ìwọ tí o fẹ́ràn òdodo, o ti fi ìdí ẹ̀tọ́ múlẹ̀; o ti dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ ati òdodo ní ilẹ̀ Jakọbu.

5 Ẹ yin OLUWA, Ọlọrun wa, ẹ jọ́sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀; mímọ́ ni OLUWA!

6 Mose ati Aaroni wà lára àwọn alufaa rẹ̀; Samuẹli pàápàá wà lára àwọn tí ń pe orúkọ rẹ̀; wọ́n ké pe OLUWA ó sì dá wọn lóhùn.

7 Ó bá wọn sọ̀rọ̀ ninu ọ̀wọ̀n ìkùukùu; wọ́n pa òfin rẹ̀ mọ́; wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí ó fún wọn.

8 OLUWA Ọlọrun wa, o dá wọn lóhùn; Ọlọrun tíí dáríjì ni ni o jẹ́ fún wọn; ṣugbọn ó gbẹ̀san ìwàkiwà wọn.

9 Ẹ yin OLUWA, Ọlọrun wa, kí ẹ sì jọ́sìn níbi òkè mímọ́ rẹ̀; nítorí pé mímọ́ ni OLUWA Ọlọrun wa.

100

1 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí OLUWA, gbogbo ilẹ̀ ayé.

2 Ẹ fi ayọ̀ sin OLUWA. Ẹ wá siwaju rẹ̀ pẹlu orin ayọ̀.

3 Ẹ mọ̀ dájú pé OLUWA ni Ọlọrun, òun ló dá wa, òun ló ni wá; àwa ni eniyan rẹ̀, àwa sì ni agbo aguntan rẹ̀.

4 Ẹ wọ ẹnubodè rẹ̀ tẹ̀yin tọpẹ́, kí ẹ sì wọ inú àgbàlá rẹ̀ tẹ̀yin tìyìn. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì máa yin orúkọ rẹ̀.

5 Nítorí OLUWA ṣeun; ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae, òtítọ́ rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

101

1 N óo kọrin ìfẹ́ ati ìdájọ́ òdodo, OLUWA, ìwọ ni n óo máa kọrin ìyìn sí.

2 N óo múra láti hu ìwà pípé pẹlu ọgbọ́n; nígbà wo ni o óo wá sọ́dọ̀ mi? N óo máa fi tọkàntọkàn rin ìrìn pípé ninu ilé mi.

3 N kò ní gba nǹkan burúkú láyè níwájú mi. Mo kórìíra ìṣe àwọn tí wọ́n tàpá sí Ọlọrun. N kò sì ní bá wọn lọ́wọ́ sí nǹkankan.

4 Èròkérò yóo jìnnà sí ọkàn mi, n kò sì ní ṣe ohun ibi kankan,

5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ níbi, n óo pa á run, n kò sì ní gba alágbèéré ati onigbeeraga láàyè.

6 N óo máa fi ojurere wo àwọn olóòótọ́ ní ilẹ̀ náà, kí wọ́n lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá sì ń hu ìwà pípé ni yóo máa sìn mí.

7 Ẹlẹ́tàn kankan kò ní gbé inú ilé mi; bẹ́ẹ̀ ni òpùrọ́ kankan kò ní dúró níwájú mi.

8 Ojoojumọ ni n óo máa pa àwọn eniyan burúkú run ní ilẹ̀ náà, n óo lé gbogbo àwọn aṣebi kúrò ninu ìlú OLUWA.

102

1 Gbọ́ adura mi, OLUWA; kí o sì jẹ́ kí igbe mi dé ọ̀dọ̀ rẹ.

2 Má yọwọ́ lọ́ràn mi lọ́jọ́ ìṣòro! Dẹtí sí adura mi; kí o sì tètè dá mi lóhùn nígbà tí mo bá ké pè ọ́.

3 Nítorí ọjọ́ ayé mi ń kọjá lọ bí èéfín, eegun mi gbóná bí iná ààrò.

4 Ìdààmú bá ọkàn mi, mo rọ bíi koríko, tóbẹ́ẹ̀ tí mo gbàgbé láti jẹun.

5 Nítorí igbe ìrora mi, mo rù kan eegun.

6 Mo dàbí igúnnugún inú aṣálẹ̀, àní, bí òwìwí inú ahoro.

7 Mo dùbúlẹ̀ láìlè sùn, mo dàbí ẹyẹ tí ó dá wà lórí òrùlé.

8 Àwọn ọ̀tá ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru, àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi ń fi orúkọ mi ṣépè.

9 Mò ń jẹ eérú bí oúnjẹ, mo sì ń mu omijé mọ́ omi

10 nítorí ìrúnú ati ibinu rẹ; o gbé mi sókè, o sì jù mí nù.

11 Ọjọ́ ayé mi ń lọ bí òjìji àṣáálẹ́, mo sì ń rọ bíi koríko.

12 Bẹ́ẹ̀ sì ni ìwọ OLUWA gúnwà títí lae, ọlá rẹ sì wà láti ìran dé ìran.

13 Ìwọ óo dìde, o óo sì ṣàánú Sioni, nítorí ó tó àkókò láti fi ojú àánú wò ó. Àkókò tí o dá tó.

14 Nítorí àwọn òkúta rẹ̀ ṣe iyebíye lójú àwọn iranṣẹ rẹ, àánú rẹ̀ sì ṣeni bí ó tilẹ̀ ti wó dà sinu erùpẹ̀.

15 Àwọn orílẹ̀-èdè yóo máa bẹ̀rù orúkọ OLUWA, gbogbo ọba ayé ni yóo sì máa bẹ̀rù ògo rẹ̀.

16 Nítorí OLUWA yóo tún Sioni kọ́, yóo sì fara hàn ninu ògo rẹ̀.

17 Yóo gbọ́ adura àwọn aláìní, kò sì ní kẹ́gàn ẹ̀bẹ̀ wọn.

18 Kí ẹ kọ èyí sílẹ̀ fún ìran tí ń bọ̀, kí àwọn ọmọ tí a kò tíì bí lè máa yin OLUWA,

19 pé OLUWA bojú wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀, láti ọ̀run ni ó ti bojú wo ayé;

20 láti gbọ́ ìkérora àwọn ìgbèkùn, ati láti dá àwọn tí a dájọ́ ikú fún sílẹ̀.

21 Kí á lè pòkìkí orúkọ OLUWA ní Sioni, kí á sì máa yìn ín lógo ní Jerusalẹmu,

22 nígbà tí àwọn orílẹ̀-èdè bá péjọ tàwọn tọba wọn, láti sin OLUWA.

23 Ó ti gba agbára mi ní àìpé ọjọ́, ó ti gé ọjọ́ ayé mi kúrú.

24 Mo ní, “Áà! Ọlọrun mi, má mú mi kúrò láyé láìpé ọjọ́, ìwọ tí ọjọ́ ayé rẹ kò lópin.”

25 Láti ìgbà laelae ni o ti fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ sì ni ọ̀run.

26 Wọn óo parẹ́ ṣugbọn ìwọ yóo wà títí lae; gbogbo wọn yóo gbó bí aṣọ, o óo pààrọ̀ wọn bí aṣọ; wọn yóo sì di ohun ìpatì.

27 Ṣugbọn ìwọ wà bákan náà, ọjọ́ ayé rẹ kò sì lópin.

28 Ọmọ àwọn iranṣẹ rẹ yóo ní ibùgbé; bẹ́ẹ̀ ni arọmọdọmọ wọn yóo fẹsẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.

103

1 Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi, fi tinútinú yin orúkọ rẹ̀ mímọ́.

2 Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi, má sì ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,

3 ẹni tí ó ń dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́, tí ó ń wo gbogbo àrùn rẹ sàn;

4 ẹni tí ó ń yọ ẹ̀mí rẹ kúrò ninu ọ̀fìn, tí ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ati àánú dé ọ ládé.

5 Ẹni tí ó ń fi ohun dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn, tí ó fi ń sọ agbára ìgbà èwe rẹ dọ̀tun bíi ti idì.

6 OLUWA a máa dáni láre a sì máa ṣe ìdájọ́ òdodo fún gbogbo àwọn tí a ni lára.

7 Ó fi ọ̀nà rẹ̀ han Mose, ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ han àwọn ọmọ Israẹli.

8 Aláàánú ati olóore ni OLUWA, kì í tètè bínú, ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀.

9 Kì í fi ìgbà gbogbo báni wí, bẹ́ẹ̀ ni ibinu rẹ̀ kì í pẹ́ títí ayé.

10 Kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa, bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa bí àìdára wa.

11 Nítorí bí ọ̀run ti jìnnà sí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ṣe tóbi tó sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

12 Bí ìlà oòrùn ti jìnnà sí ìwọ oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni ó mú ẹ̀ṣẹ̀ wa jìnnà sí wa.

13 Bí baba ti máa ń ṣàánú àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA máa ń ṣàánú àwọn tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀.

14 Nítorí ó mọ ẹ̀dá wa; ó ranti pé erùpẹ̀ ni wá.

15 Ọjọ́ ayé ọmọ eniyan dàbí ti koríko, eniyan a sì máa gbilẹ̀ bí òdòdó inú igbó;

16 ṣugbọn bí afẹ́fẹ́ bá ti fẹ́ kọjá lórí rẹ̀, á rẹ̀ dànù, ààyè rẹ̀ kò sì ní ranti rẹ̀ mọ́.

17 Ṣugbọn títí ayé ni ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀, sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, òdodo rẹ̀ wà lára arọmọdọmọ wọn.

18 Ó wà lára àwọn tí ó ń pa majẹmu rẹ̀ mọ́, tí wọn sì ń ranti láti pa òfin rẹ̀ mọ́.

19 OLUWA ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ lọ́run, ó sì jọba lórí ohun gbogbo.

20 Ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, ẹ̀yin alágbára tí ẹ̀ ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀, tí ẹ sì ń fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

21 Ẹ yin OLUWA gbogbo ẹ̀yin ọmọ ogun rẹ̀, ẹ̀yin iranṣẹ rẹ̀, tí ẹ̀ ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.

22 Ẹ yin OLUWA, gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, níbi gbogbo ninu ìjọba rẹ̀. Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi.

104

1 Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi, OLUWA, Ọlọrun mi, ó tóbi pupọ, ọlá ati iyì ni ó wọ̀ bí ẹ̀wù.

2 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bora bí aṣọ, ó ta ojú ọ̀run bí ẹni taṣọ.

3 Ìwọ tí o tẹ́ àjà ibùgbé rẹ sórí omi, tí o fi ìkùukùu ṣe kẹ̀kẹ́ ogun rẹ, tí o sì ń lọ geere lórí afẹ́fẹ́.

4 Ìwọ tí o fi ẹ̀fúùfù ṣe iranṣẹ, tí o sì fi iná ati ahọ́n iná ṣe òjíṣẹ́ rẹ.

5 Ìwọ tí o gbé ayé kalẹ̀ lórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, tí kò sì le yẹ̀ laelae.

6 O fi ibú omi bò ó bí aṣọ, omi sì borí àwọn òkè ńlá.

7 Nígbà tí o bá wọn wí, wọ́n sá, nígbà tí o sán ààrá, wọ́n sá sẹ́yìn.

8 Wọ́n ṣàn kọjá lórí òkè lọ sí inú àfonífojì, sí ibi tí o yàn fún wọn.

9 O ti pa ààlà tí wọn kò gbọdọ̀ kọjá, kí wọn má baà tún bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.

10 Ìwọ ni o mú kí àwọn orísun máa tú omi jáde ní àfonífojì; omi wọn sì ń ṣàn láàrin àwọn òkè.

11 Ninu omi wọn ni gbogbo ẹranko tí ń mu, ibẹ̀ sì ni àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń rẹ òùngbẹ.

12 Lẹ́bàá orísun wọnyi ni àwọn ẹyẹ ń gbé, wọ́n sì ń kọrin lórí igi.

13 Láti ibùgbé rẹ lókè ni o tí ń bomi rin àwọn òkè ńlá. Ilẹ̀ sì mu àmutẹ́rùn nípa iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

14 Ó ń mú kí koríko dàgbà fún àwọn ẹran láti jẹ, ati ohun ọ̀gbìn fún ìlò eniyan, kí ó lè máa mú oúnjẹ jáde láti inú ilẹ̀;

15 ati ọtí waini tí ń mú inú eniyan dùn, ati epo tí ń mú ojú eniyan dán, ati oúnjẹ tí ń fún ara lókun.

16 Àwọn igi OLUWA ń mu omi ní àmutẹ́rùn, àní àwọn igi kedari Lẹbanoni tí ó gbìn.

17 Lórí wọn ni àwọn ẹyẹ ń tẹ́ ìtẹ́ wọn sí, àkọ̀ sì ń kọ́ ilé rẹ̀ sórí igi firi.

18 Òkè gíga ni ilé ewúrẹ́ igbó, abẹ́ àpáta sì ni ibùgbé ehoro.

19 O dá òṣùpá láti máa sàmì àkókò, oòrùn sì mọ àkókò wíwọ̀ rẹ̀.

20 O mú kí òkùnkùn ṣú, alẹ́ sì lẹ́, gbogbo ẹranko ìgbẹ́ sì ń jẹ kiri.

21 Àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun ń bú fún ìjẹ, wọ́n ń wo ojú Ọlọrun fún oúnjẹ.

22 Nígbà tí oòrùn bá là, wọn á wọ́ lọ; wọn á lọ dùbúlẹ̀ sinu ihò wọn.

23 Ọmọ eniyan á sì jáde lọ síbi iṣẹ́ rẹ̀, á lọ síbi làálàá rẹ̀ títí di àṣáálẹ́.

24 OLUWA, ìyanu ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ! Ọgbọ́n ni o fi dá gbogbo wọn. Ayé kún fún àwọn ẹ̀dá rẹ.

25 Ẹ wo òkun bí ó ti tóbi tí ó sì fẹ̀, ó kún fún ọ̀kẹ́ àìmọye ẹ̀dá, nǹkan abẹ̀mí kéékèèké ati ńláńlá.

26 Ibẹ̀ ni ọkọ̀ ojú omi ń gbà lọ, ati Lefiatani tí o dá láti máa ṣeré ninu òkun.

27 Ojú rẹ ni gbogbo wọn ń wò, fún ìpèsè oúnjẹ ní àkókò.

28 Nígbà tí o bá fún wọn, wọn á kó o jọ, nígbà tí o bá la ọwọ́, wọn á jẹ ohun dáradára ní àjẹyó.

29 Bí o bá fojú pamọ́, ẹ̀rù á bà wọ́n, bí o bá gba ẹ̀mí wọn, wọn á kú, wọn á sì pada di erùpẹ̀.

30 Nígbà tí o rán ẹ̀mí rẹ jáde, wọ́n di ẹ̀dá alààyè, o sì sọ orí ilẹ̀ di ọ̀tun.

31 Kí ògo OLUWA máa wà títí lae, kí OLUWA máa yọ̀ ninu iṣẹ́ rẹ̀.

32 Ẹni tí ó wo ilẹ̀, tí ilẹ̀ mì tìtì, tí ó fọwọ́ kan òkè, tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí yọ èéfín.

33 N óo kọrin ìyìn sí OLUWA níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láàyè. N óo máa kọrin ìyìn sí Ọlọrun mi, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀mí mi bá ń bẹ.

34 Kí àṣàrò ọkàn mi kí ó dùn mọ́ ọn ninu nítorí mo láyọ̀ ninu OLUWA.

35 Kí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ parẹ́ lórí ilẹ̀ ayé, kí àwọn eniyan burúkú má sí mọ́. Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi! Yin OLUWA!

105

1 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè.

2 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọ orin ìyìn sí i, ẹ sọ nípa gbogbo iṣẹ́ ribiribi rẹ̀.

3 Ẹ máa fi orúkọ mímọ́ rẹ̀ yangàn, kí ọkàn àwọn tí ń wá OLUWA ó máa yọ̀.

4 Ẹ wá ojurere OLUWA ati agbára rẹ̀, ẹ máa wá ojurere rẹ̀ nígbà gbogbo.

5 Ẹ ranti iṣẹ́ ribiribi tí ó ti ṣe, ẹ ranti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ati ìdájọ́ rẹ̀.

6 Ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.

7 OLUWA ni Ọlọrun wa, ìdájọ́ rẹ̀ kárí gbogbo ayé.

8 Títí lae ni ó ń ranti majẹmu rẹ̀, ó ranti àṣẹ tí ó pa fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,

9 majẹmu tí ó bá Abrahamu dá, ìlérí tí ó fi ìbúra ṣe fún Isaaki,

10 tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí òfin, àní fún Israẹli gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ayérayé,

11 ó ní: “Ẹ̀yin ni n óo fi ilẹ̀ Kenaani fún, yóo jẹ́ ìpín yín tí ẹ óo jogún.”

12 Nígbà tí wọ́n kéré ní iye, tí wọn kò tíì pọ̀ rárá, tí wọn sì jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ náà,

13 tí wọn ń káàkiri láti orílẹ̀-èdè dé orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan dé òmíràn,

14 kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ni wọ́n lára, ó bá àwọn ọba wí nítorí wọn.

15 Ó ní, “Ẹ kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe àwọn wolii mi níbi.”

16 Nígbà kan, ó mú kí ìyàn jà ní ilẹ̀ náà: ó ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ mọ́ wọn lẹ́nu.

17 Ṣugbọn ó kọ́ rán ọkunrin kan ṣáájú wọn, Josẹfu, ẹni tí a tà lẹ́rú.

18 Wọ́n so ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ mọ́ ọn lẹ́sẹ̀, wọ́n ti ọrùn rẹ̀ bọ irin,

19 títí ìgbà tí ohun tí ó sọ fi ṣẹ, tí OLUWA sì jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

20 Ọba ranṣẹ pé kí wọ́n tú u sílẹ̀, aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè sì dá a sílẹ̀.

21 Ó fi jẹ aláṣẹ ilé rẹ̀, ati alákòóso gbogbo nǹkan ìní rẹ̀;

22 láti máa ṣe olórí àwọn ìjòyè rẹ̀, kí ó sì máa kọ́ àwọn àgbà ìlú ní ìmọ̀.

23 Lẹ́yìn náà, Israẹli dé sí Ijipti, Jakọbu ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Hamu.

24 OLUWA mú kí àwọn eniyan rẹ̀ pọ̀ sí i, ó sì mú kí wọ́n lágbára ju àwọn ọ̀tá wọn lọ.

25 Ó yí àwọn ará Ijipti lọ́kàn pada, tóbẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi kórìíra àwọn eniyan rẹ̀, tí wọ́n sì hùwà àrékérekè sí àwọn iranṣẹ rẹ̀.

26 Ó rán Mose, iranṣẹ rẹ̀, ati Aaroni, ẹni tí ó yàn.

27 Wọ́n ṣe iṣẹ́ àmì rẹ̀ ní ilẹ̀ náà, wọ́n sì ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ní ilẹ̀ Hamu,

28 Ọlọrun rán òkùnkùn, ilẹ̀ sì ṣú, ṣugbọn wọ́n ṣe oríkunkun sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó sì mú kí ẹja wọn kú.

30 Ọ̀pọ̀lọ́ ń tú jáde ní ilẹ̀ wọn, títí kan ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.

31 Ọlọrun sọ̀rọ̀, eṣinṣin sì rọ́ dé, iná aṣọ sì bo gbogbo ilẹ̀ wọn.

32 Ó rọ̀jò yìnyín lé wọn lórí, mànàmáná sì ń kọ káàkiri ilẹ̀ wọn.

33 Ó kọlu àjàrà ati igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn, ó sì wó àwọn igi ilẹ̀ wọn.

34 Ó sọ̀rọ̀, àwọn eṣú sì rọ́ dé, ati àwọn tata tí kò lóǹkà;

35 wọ́n jẹ gbogbo ewé tí ó wà ní ilẹ̀ wọn, ati gbogbo èso ilẹ̀ náà.

36 Ó kọlu gbogbo àkọ́bí ilẹ̀ wọn, àní, gbogbo àrẹ̀mọ ilẹ̀ wọn.

37 Lẹ́yìn náà, ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde, tàwọn ti fadaka ati wúrà, kò sì sí ẹnikẹ́ni ninu ẹ̀yà kankan tí ó ṣe àìlera.

38 Inú àwọn ará Ijipti dùn nígbà tí wọ́n jáde, nítorí ẹ̀rù àwọn ọmọ Israẹli ń bà wọ́n.

39 OLUWA ta ìkùukùu bò wọ́n, ó sì pèsè iná láti tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn lóru.

40 Wọ́n bèèrè ẹran, ó fún wọn ní àparò, ó sì pèsè oúnjẹ àjẹtẹ́rùn fún wọn láti ọ̀run.

41 Ó la àpáta, omi tú jáde, ó sì ṣàn ninu aṣálẹ̀ bí odò.

42 Nítorí pé ó ranti ìlérí mímọ́ rẹ̀, ati Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀.

43 Ó fi ayọ̀ kó àwọn eniyan rẹ̀ jáde, ó kó àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ jáde pẹlu orin.

44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, wọ́n sì jogún èrè iṣẹ́ àwọn eniyan náà.

45 Kí wọ́n lè máa mú àṣẹ rẹ̀ ṣẹ, kí wọ́n sì máa pa òfin rẹ̀ mọ́. Ẹ yin OLUWA!

106

1 Ẹ yin OLUWA! Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2 Ta ló lè sọ iṣẹ́ agbára OLUWA tán? Ta ló sì lè fi gbogbo ìyìn rẹ̀ hàn?

3 Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń ṣe ẹ̀tọ́, àwọn tí ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà nígbà gbogbo.

4 Ranti mi, OLUWA, nígbà tí o bá ń ṣí ojurere wo àwọn eniyan rẹ. Ràn mí lọ́wọ́ nígbà tí o bá ń gbà wọ́n là.

5 Kí n lè rí ire àwọn àyànfẹ́ rẹ kí n lè ní ìpín ninu ayọ̀ àwọn eniyan rẹ, kí n sì lè máa ṣògo pẹlu àwọn tí ó jẹ́ eniyan ìní rẹ.

6 A ti ṣẹ̀, àtàwa, àtàwọn baba wa, a ti ṣe àìdára, a sì ti hùwà burúkú.

7 Nígbà tí àwọn baba ńlá wa wà ní Ijipti, wọn kò náání iṣẹ́ ìyanu rẹ, wọn kò sì ranti bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ti pọ̀ tó. Ṣugbọn wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo lẹ́bàá òkun pupa.

8 Sibẹsibẹ, ó gbà wọ́n là, nítorí orúkọ rẹ̀; kí ó lè fi títóbi agbára rẹ̀ hàn.

9 Ó bá òkun pupa wí, òkun pupa gbẹ, ó sì mú wọn la ibú já bí ẹni rìn ninu aṣálẹ̀.

10 Ó gbà wọ́n là lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wọn, ó sì kó wọn yọ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.

11 Omi bo àwọn ọ̀tá wọn, ẹyọ ẹnìkan kò sì là.

12 Nígbà náà ni wọ́n tó gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ gbọ́, wọ́n sì kọrin yìn ín.

13 Kò pẹ́ tí wọ́n tún fi gbàgbé iṣẹ́ rẹ̀, wọn kò sì dúró gba ìmọ̀ràn rẹ̀.

14 Wọ́n ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ní aṣálẹ̀, wọ́n sì dán Ọlọrun wò.

15 Ó fún wọn ní ohun tí wọ́n bèèrè, ṣugbọn ó fi àìsàn ajẹnirun ṣe wọ́n.

16 Nígbà tí wọ́n ṣe ìlara sí Mose ninu ibùdó, ati sí Aaroni, ẹni mímọ́ OLÚWA.

17 Ilẹ̀ yanu, ó gbé Datani mì, ó sì bo Abiramu ati àwọn tí ó tẹ̀lé e mọ́lẹ̀.

18 Iná sọ láàrin wọn, ó sì jó àwọn eniyan burúkú náà run.

19 Wọ́n yá ère ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù ní Horebu, wọ́n sì bọ ère tí wọ́n dà.

20 Wọ́n gbé ògo Ọlọrun fún ère mààlúù tí ń jẹ koríko.

21 Wọ́n gbàgbé Ọlọrun, Olùgbàlà wọn, tí ó ṣe iṣẹ́ ribiribi ní Ijipti,

22 ó ṣe, iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu, ati ohun ẹ̀rù lẹ́bàá òkun pupa.

23 Nítorí náà ni ó ṣe wí pé òun yóo pa wọ́n run, bí kì í bá ṣe ti Mose, àyànfẹ́ rẹ̀, tí ó dúró níwájú rẹ̀, tí ó sì ṣìpẹ̀, láti yí ibinu OLUWA pada, kí ó má baà pa wọ́n run.

24 Wọn kò bìkítà fún ilẹ̀ dáradára náà, wọn kò sì ní igbagbọ ninu ọ̀rọ̀ OLUWA.

25 Wọ́n ń kùn ninu àgọ́ wọn, wọn kò sì fetí sí ohùn OLUWA.

26 Nítorí náà, ó gbé ọwọ́ sókè, ó búra fún wọn pé òun yóo jẹ́ kí wọ́n kú sí aṣálẹ̀,

27 ati pé òun yóo fọ́n àwọn ìran wọn káàkiri àwọn orílẹ̀-èdè.

28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali ti Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí wọ́n rú sí òkú.

29 Wọ́n fi ìwà burúkú wọn mú OLUWA bínú, àjàkálẹ̀ àrùn sì bẹ́ sílẹ̀ láàrin wọn.

30 Nígbà náà ni Finehasi dìde, ó bẹ̀bẹ̀ fún wọn, àjàkálẹ̀ àrùn sì dáwọ́ dúró.

31 A sì kà á kún òdodo fún un, láti ìrandíran títí lae.

32 Wọ́n mú OLUWA bínú lẹ́bàá omi Meriba, wọ́n sì fi tiwọn kó bá Mose,

33 nítorí wọ́n mú Mose bínú, ọ̀rọ̀ tí kò yẹ sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.

34 Wọn kò pa àwọn eniyan ilẹ̀ náà run, gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti pa á láṣẹ fún wọn,

35 ṣugbọn wọ́n dara pọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè náà, wọ́n sì kọ́ ìṣe wọn.

36 Wọ́n bọ àwọn oriṣa wọn, èyí sì fa ìpalára fún wọn.

37 Wọ́n fi àwọn ọmọkunrin ati ọmọbinrin wọn bọ oriṣa.

38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, àní, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkunrin, ati ti àwọn ọmọbinrin wọn, tí wọ́n fi bọ àwọn oriṣa ilẹ̀ Kenaani; wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di aláìmọ́.

39 Nítorí náà, wọ́n fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì sọ ara wọn di alágbèrè.

40 Nígbà náà ni inú bí OLUWA sí àwọn eniyan rẹ̀, ó sì kórìíra àwọn ẹni ìní rẹ̀.

41 Ó fi wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn lọ́wọ́, títí tí àwọn tí ó kórìíra wọn fi jọba lé wọn lórí.

42 Àwọn ọ̀tá wọn ni wọ́n lára, wọ́n sì fi agbára mú wọn sìn.

43 Ọpọlọpọ ìgbà ni ó gbà wọ́n sílẹ̀, ṣugbọn wọ́n ti pinnu láti máa tàpá sí i, OLUWA sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44 Sibẹsibẹ, ninu ìnira wọn, ó ṣàánú wọn, nígbà tí ó gbọ́ igbe wọn.

45 Nítorí tiwọn, ó ranti majẹmu tí ó dá, ó sì yí ìpinnu rẹ̀ pada nítorí ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

46 Ó jẹ́ kí àánú wọn ṣe gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn.

47 Gbà wá, OLUWA, Ọlọrun wa, kí o sì kó wa kúrò láàrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, kí á lè máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí á sì lè máa ṣògo ninu ìyìn rẹ.

48 Ẹni ìyìn ni OLUWA, Ọlọrun Israẹli, lae ati laelae. Kí gbogbo eniyan máa wí pé, “Amin!” Ẹ yin OLUWA!

107

1 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun, nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2 Kí àwọn tí OLUWA ti rà pada kí ó wí bẹ́ẹ̀, àní, àwọn tí ó yọ kúrò ninu ìpọ́njú,

3 tí ó kó wọn jáde kúrò láàrin àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì, láti ìhà ìlà oòrùn ati láti ìhà ìwọ̀ oòrùn, láti ìhà àríwá ati láti ìhà gúsù.

4 Àwọn kan ń káàkiri ninu aṣálẹ̀, wọn kò sì rí ọ̀nà dé ìlú tí wọ́n lè máa gbé.

5 Ebi pa wọ́n, òùngbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ̀ wọ́n wá láti inú.

6 Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò ninu ìṣẹ́ wọn.

7 Ó kó wọn gba ọ̀nà tààrà jáde, lọ sí ìlú tí wọ́n lè máa gbé.

8 Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, àní nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún àwọn ọmọ eniyan.

9 Nítorí pé ó fi omi tẹ́ àwọn tí òùngbẹ ń gbẹ lọ́rùn, ó sì fi oúnjẹ dáradára bọ́ àwọn tí ebi ń pa ní àbọ́yó.

10 Àwọn kan jókòó ninu òkùnkùn pẹlu ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn, wọ́n wà ninu ìgbèkùn ati ìpọ́njú, a sì fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè wọ́n,

11 nítorí pé wọ́n tàpá sí òfin Ọlọrun, wọ́n sì pẹ̀gàn ìmọ̀ràn ọ̀gá ògo.

12 Làálàá mú kí agara dá ọkàn wọn, wọ́n ṣubú lulẹ̀ láìsí olùrànlọ́wọ́.

13 Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn, ó sì gbà wọ́n ninu ìṣẹ́ wọn.

14 Ó yọ wọ́n kúrò ninu òkùnkùn ati ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn, ó sì já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn.

15 Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, àní nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún eniyan.

16 Nítorí pé ó fọ́ ìlẹ̀kùn idẹ, ó sì gé ọ̀pá ìdábùú irin ní àgéjá.

17 Àwọn kan ninu wọn di òmùgọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ojú sì pọ́n wọn nítorí àìdára wọn.

18 Oúnjẹ rùn sí wọn, wọ́n sì súnmọ́ bèbè ikú.

19 Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn, ó sì yọ wọ́n ninu ìṣẹ́ wọn.

20 Ó sọ̀rọ̀, ó sì mú wọn lára dá, ó tún kó wọn yọ ninu ìparun.

21 Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, àní, nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún eniyan.

22 Kí wọn máa rú ẹbọ ọpẹ́, kí wọn sì máa fi orin ayọ̀ ròyìn iṣẹ́ rẹ̀.

23 Àwọn kan wọ ọkọ̀ ojú omi, wọ́n ń ṣòwò lórí agbami òkun,

24 wọ́n rí ìṣe OLUWA, àní iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ninu ibú.

25 Ó pàṣẹ, ìjì líle sì bẹ̀rẹ̀ sí jà, tóbẹ́ẹ̀ tí ìgbì omi fi ru sókè.

26 Àwọn ọkọ̀ ojú omi fò sókè roro, wọ́n sì tún já wá sílẹ̀ dòò, sinu ibú, jìnnìjìnnì bò wọ́n ninu ewu tí wọ́n wà.

27 Wọ́n ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n káàkiri bí ọ̀mùtí, gbogbo ọgbọ́n sì parẹ́ mọ́ wọn ninu.

28 Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn, ó sì yọ wọ́n ninu ìṣẹ́ wọn.

29 Ó mú kí ìgbì dáwọ́ dúró, ó sì mú kí ríru omi òkun rọlẹ̀ wọ̀ọ̀.

30 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí yọ̀ nígbà tí ilẹ̀ rọ̀, ó sì mú kí wọ́n gúnlẹ̀ sí èbúté ìfẹ́ wọn.

31 Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀, àní nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún eniyan.

32 Kí wọn gbé e ga láàrin ìjọ eniyan, kí wọn sì yìn ín ní àwùjọ àwọn àgbà.

33 Ó sọ odò di aṣálẹ̀, ó sọ orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ,

34 ó sọ ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ oníyọ̀, nítorí ìwà burúkú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

35 Ó sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, ó sì sọ ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi.

36 Ó jẹ́ kí àwọn tí ebi ń pa máa gbé ibẹ̀, wọ́n sì tẹ ìlú dó, láti máa gbé.

37 Wọ́n dáko, wọ́n gbin àjàrà, wọ́n sì kórè lọpọlọpọ.

38 Ó bukun wọn, ó mú kí wọn bí sí i lọpọlọpọ, kò sì jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọ́n dínkù.

39 Nígbà tí wọ́n dínkù, tí a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, nípa ìnira, ìpọ́njú, ati ìṣòro,

40 ó da ẹ̀gàn lu àwọn ìjòyè, ó sì mú kí wọn máa rìn kiri ní aṣálẹ̀, níbi tí kò sí ọ̀nà.

41 Ṣugbọn ó yọ aláìní kúrò ninu ìpọ́njú, ó sì mú kí ìdílé wọn pọ̀ sí i bí agbo ẹran.

42 Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn, a sì pa àwọn eniyan burúkú lẹ́nu mọ́.

43 Kí ẹni tí ó gbọ́n kíyèsí nǹkan wọnyi; kí ó sì fi òye gbé ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀.

108

1 Ọkàn mi dúró ṣinṣin, Ọlọrun ọkàn mi dúró ṣinṣin. N óo kọrin, n óo sì máa yìn ọ́. Jí, ìwọ ọkàn mi!

2 Ẹ jí ẹ̀yin ohun èlò ìkọrin ati hapu! Èmi fúnra mi náà yóo jí ní òwúrọ̀ kutukutu,

3 OLUWA, n óo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ láàrin àwọn eniyan, n óo sì máa kọrin ìyìn sí ọ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.

4 Nítorí pé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi, ó ga ju ọ̀run lọ, òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

5 Kí á gbé ọ ga ju ọ̀run lọ, Ọlọrun, kí ògo rẹ sì kárí gbogbo ayé.

6 Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là, fi ọwọ́ agbára rẹ gbà wá, kí o sì dá mi lóhùn.

7 Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀, ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu, n óo sì pín àfonífojì Sukotu.

8 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase. Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.

9 Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé, n óo sì hó ìhó ìṣẹ́gun lórí Filistia.”

10 Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà? Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?

11 Ọlọrun, o kò ha ti kọ̀ wá sílẹ̀? Ọlọrun, o ò bá àwọn ọmọ ogun wa lọ sójú ogun mọ́.

12 Ràn wá lọ́wọ́, bá wa gbógun ti àwọn ọ̀tá wa, nítorí pé asán ni ìrànlọ́wọ́ eniyan.

13 Pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọ́run, a óo ṣe akin; nítorí òun ni yóo tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

109

1 Má dákẹ́, ìwọ Ọlọrun tí mò ń yìn.

2 Nítorí pé ẹnu àwọn eniyan burúkú ati ti àwọn ẹlẹ́tàn kò dákẹ́, wọ́n ń sọ̀rọ̀ èké nípa mi.

3 Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ káàkiri nípa mi, wọ́n sì ń gbógun tì mí láìnídìí.

4 Èmi fẹ́ràn wọn; ṣugbọn ẹ̀sùn ni wọ́n fi ń kàn mí, sibẹ, adura ni mò ń gbà fún wọn.

5 Ibi ni wọ́n fí ń san oore fún mi, ìkórìíra ni wọ́n sì fi ń san ìfẹ́ tí mo ní sí wọn.

6 Yan eniyan burúkú tì í, jẹ́ kí ẹlẹ́sùn èké kó o sẹ́jọ́.

7 Nígbà tí a bá ń dá ẹjọ́ rẹ̀, jẹ́ kí wọn dá a lẹ́bi; kí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ di ọ̀ràn sí i lọ́rùn.

8 Ṣe é ní ẹlẹ́mìí kúkúrú, kí ohun ìní rẹ̀ di ti àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà.

9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìníbaba, kí aya rẹ̀ di opó.

10 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di alárìnká, kí wọn máa ṣagbe kiri; kí á lé wọn jáde kúrò ninu ahoro tí wọn ń gbé.

11 Kí ẹni tí ó jẹ lówó gba gbogbo ohun ìní rẹ̀, kí ẹni ẹlẹ́ni sì kó èrè iṣẹ́ rẹ̀.

12 Kí ó má bá aláàánú pàdé, kí ẹnikẹ́ni má sì ṣàánú àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ti di aláìníbaba.

13 Kí ìran rẹ̀ run, kí orúkọ rẹ̀ parẹ́ lórí àwọn ọmọ rẹ̀.

14 Kí OLUWA máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀, kí ó má sì pa ẹ̀ṣẹ̀ ìyá rẹ̀ rẹ́.

15 Kí OLUWA máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ wọn nígbà gbogbo, kí á má sì ranti ìran wọn mọ́ láyé.

16 Nítorí pé kò ronú láti ṣàánú, ṣugbọn ó ṣe inúnibíni talaka ati aláìní, ati sí oníròbìnújẹ́ títí a fi pa wọ́n.

17 Ó fẹ́ràn láti máa ṣépè; nítorí náà kí èpè rẹ̀ dà lé e lórí; inú rẹ̀ kò dùn sí ìre, nítorí náà kí ìre jìnnà sí i.

18 Ó gbé èpè wọ̀ bí ẹ̀wù, kí èpè mù ún bí omi, kí ó sì wọ inú egungun rẹ̀ dé mùdùnmúdùn.

19 Kí èpè di aṣọ ìbora fún un, ati ọ̀já ìgbànú.

20 Bẹ́ẹ̀ ni kí OLUWA ṣe sí àwọn ọ̀tá mi, àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi nípa mi!

21 Ṣugbọn, ìwọ OLUWA Ọlọrun mi, gbèjà mi nítorí orúkọ rẹ, gbà mí! Nítorí ìfẹ́ rere rẹ tí kì í yẹ̀.

22 Nítorí pé talaka ati aláìní ni mí, ọkàn mí bàjẹ́ lọpọlọpọ.

23 Mò ń parẹ́ lọ bí òjìji àṣáálẹ́, a ti gbọ̀n mí dànù bí eṣú.

24 Ẹsẹ̀ mi kò ranlẹ̀ mọ́ nítorí ààwẹ̀ gbígbà, mo rù kan egungun.

25 Mo di ẹni ẹ̀gàn níwájú àwọn ọ̀tá mi, wọ́n ń wò mí ní àwòmirí.

26 Ràn mí lọ́wọ́, OLUWA, Ọlọrun mi, gbà mí, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni èyí, kí wọn mọ̀ pé, ìwọ OLUWA ni o ṣe é.

28 Kí wọn máa ṣépè, ṣugbọn kí ìwọ máa súre. Kí ojú ti àwọn alátakò mi, kí inú èmi, iranṣẹ rẹ, sì máa dùn.

29 Kí ìtìjú bo àwọn ọ̀tá mi bi aṣọ, àní, kí wọn gbé ìtìjú wọ̀ bí ẹ̀wù.

30 N óo máa fi ẹnu mi yin OLUWA gidigidi, àní, n óo máa yìn ín ní àwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan.

31 Nítorí pé ó dúró ti aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ó dájọ́ ikú fún un.

110

1 OLUWA wí fún oluwa mi, ọba, pé, “Jókòó sí apá ọ̀tún mi, títí tí n óo fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”

2 OLUWA yóo na ọ̀pá àṣẹ rẹ tí ó lágbára láti Sioni. O óo jọba láàrin àwọn ọ̀tá rẹ.

3 Àwọn eniyan rẹ yóo fi tọkàntọkàn fa ara wọn kalẹ̀, lọ́jọ́ tí o bá ń kó àwọn ọmọ ogun rẹ jọ lórí òkè mímọ́. Àwọn ọ̀dọ́ yóo jáde tọ̀ ọ́ wá bí ìrì òwúrọ̀.

4 OLUWA ti búra, kò sì ní yí ọkàn rẹ̀ pada, pé, “Alufaa ni ọ́ títí lae, nípasẹ̀ Mẹlikisẹdẹki.”

5 OLUWA wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, yóo rún àwọn ọba wómúwómú ní ọjọ́ ibinu rẹ̀.

6 Yóo ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, ọpọlọpọ òkú ni yóo sì sùn ninu wọn; yóo sì run àwọn ìjòyè káàkiri ilẹ̀ ayé.

7 Ọba yóo mu omi ninu odò ẹ̀bá ọ̀nà, nítorí náà yóo sì gbé orí rẹ̀ sókè bí aṣẹ́gun.

111

1 Ẹ yin OLUWA! N óo dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA tọkàntọkàn, láàrin àwọn olódodo, ati ní àwùjọ àwọn eniyan.

2 Iṣẹ́ OLUWA tóbi, àwọn tí ó nífẹ̀ẹ́ sí i sì ń wá a kiri.

3 Iṣẹ́ rẹ̀ lọ́lá, ó sì lógo, òdodo rẹ̀ sì wà títí lae.

4 OLUWA mú kí á máa ranti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, olóore ọ̀fẹ́ ni OLUWA, àánú rẹ̀ sì pọ̀.

5 A máa pèsè oúnjẹ fún àwọn tí wọn bẹ̀rù rẹ̀, a sì máa ranti majẹmu rẹ̀ títí lae.

6 Ó ti fi agbára iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn eniyan rẹ̀, nípa fífún wọn ní ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn.

7 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ tọ́, ó sì tọ̀nà, gbogbo ìlànà rẹ̀ sì dájú.

8 Wọ́n wà títí lae ati laelae, ní òtítọ́ ati ìdúróṣinṣin.

9 Ó ṣètò ìràpadà fún àwọn eniyan rẹ̀, ó fi ìdí majẹmu rẹ̀ múlẹ̀ títí lae, mímọ́ ni orúkọ rẹ̀, ó sì lọ́wọ̀.

10 Ìbẹ̀rù OLUWA ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, gbogbo àwọn tí ó bá ń tẹ̀lé ìlànà rẹ̀, á máa ní ìmọ̀ pípé. Títí lae ni ìyìn rẹ̀.

112

1 Ẹ yin OLUWA! Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bẹ̀rù OLUWA, tí inú rẹ̀ sì dùn lọpọlọpọ sí òfin rẹ̀.

2 Àwọn arọmọdọmọ rẹ̀ yóo jẹ́ alágbára láyé, a óo sì bukun ìran ẹni tí ó dúró ṣinṣin.

3 Ọlá ati ọlà yóo wà ní ilé rẹ̀, Òdodo rẹ̀ wà títí lae.

4 Ìmọ́lẹ̀ yóo tàn fún olódodo ninu òkùnkùn, olóore ọ̀fẹ́ ni OLUWA, aláàánú ni, a sì máa ṣòdodo.

5 Yóo máa dára fún ẹni tí ó bá lójú àánú, tí ó sì ń yáni ní nǹkan, tí ó ń ṣe ẹ̀tọ́ ní gbogbo ọ̀nà.

6 A kò ní ṣí olódodo ní ipò pada lae, títí ayé ni a óo sì máa ranti rẹ̀.

7 Ìròyìn ibi kì í bà á lẹ́rù, ọkàn rẹ̀ dúró ṣinṣin, ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

8 Ọkàn rẹ̀ a máa balẹ̀, ẹ̀rù kì í bà á, níkẹyìn, èrò rẹ̀ a sì máa ṣẹ lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.

9 Ó lawọ́, á máa ṣoore fún àwọn talaka, òdodo rẹ̀ wà títí lae, yóo di alágbára, a óo sì dá a lọ́lá.

10 Ìbànújẹ́ yóo bá eniyan burúkú nígbà tí ó bá rí i. Yóo pa eyín keke, yóo pòórá, ìfẹ́ rẹ̀ yóo sì di asán.

113

1 Ẹ yin OLUWA! Ẹ yìn ín, ẹ̀yin iranṣẹ OLUWA. Ẹ yin orúkọ OLUWA.

2 Kí á yin orúkọ OLUWA, láti ìsinsìnyìí lọ títí laelae.

3 Láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn, kí á máa yin orúkọ OLUWA.

4 OLUWA ju gbogbo orílẹ̀-èdè lọ, ògo rẹ̀ sì ga ju ọ̀run lọ.

5 Ta ló dàbí OLUWA Ọlọrun wa, tí ó gúnwà sí òkè ọ̀run,

6 ẹni tí ó bojú wo ilẹ̀ láti wo ọ̀run ati ayé?

7 Ó gbé talaka dìde láti inú erùpẹ̀, ó sì gbé aláìní sókè láti orí eérú,

8 láti mú wọn jókòó láàrin àwọn ìjòyè, àní, àwọn ìjòyè àwọn eniyan rẹ̀.

9 Ó sọ àgàn di ọlọ́mọ, ó sọ ọ́ di abiyamọ onínúdídùn. Ẹ máa yin OLUWA.

114

1 Nígbà tí Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti, tí àwọn ọmọ Jakọbu jáde kúrò láàrin àwọn tí ń sọ èdè àjèjì,

2 Juda di ilé mímọ́ rẹ̀, Israẹli sì di ìjọba rẹ̀.

3 Òkun rí i, ó sá, Jọdani rí i, ó pada sẹ́yìn.

4 Àwọn òkè ńláńlá ń fò bí àgbò, àwọn òkè kéékèèké ń fò bí ọmọ aguntan.

5 Kí ló dé, tí o fi sá, ìwọ òkun? Kí ló ṣẹlẹ̀ tí o fi pada sẹ́yìn, ìwọ Jọdani?

6 Ẹ̀yin òkè ńlá, kí ló dé tí ẹ fi fò bí àgbò? Ẹ̀yin òkè kéékèèké, kí ló ṣẹlẹ̀ tí ẹ fi fò bí ọmọ aguntan?

7 Wárìrì níwájú OLUWA, ìwọ ilẹ̀, wárìrì níwájú Ọlọrun Jakọbu.

8 Ẹni tí ó sọ àpáta di adágún omi, tí ó sì sọ akọ òkúta di orísun omi.

115

1 Ògo kì í ṣe fún wa, OLUWA, Kì í ṣe fún wa, orúkọ rẹ nìkan ṣoṣo ni kí á yìn lógo, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, ati nítorí òtítọ́ rẹ.

2 Kí ló dé tí àwọn orílẹ̀-èdè yóo fi bèèrè pé, níbo ni Ọlọrun wa wà?

3 Ọlọrun wa wà ní ọ̀run, ó ń ṣe ohun tí ó wù ú.

4 Fadaka ati wúrà ni ère tiwọn, iṣẹ́ ọwọ́ eniyan ni wọ́n.

5 Wọ́n ní ẹnu, ṣugbọn wọn kò lè sọ̀rọ̀, wọ́n lójú, ṣugbọn wọn kò ríran.

6 Wọ́n létí, ṣugbọn wọn kò gbọ́ràn, wọ́n nímú, ṣugbọn wọn kò gbóòórùn.

7 Wọ́n lọ́wọ́, ṣugbọn wọn kò lè lò ó, wọ́n lẹ́sẹ̀, ṣugbọn wọn kò lè rìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò lè gbin.

8 Àwọn tí ó ń yá àwọn ère náà dàbí wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé wọn.

9 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

10 Ẹ̀yin ìdílé Aaroni, ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

11 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ gbẹ́kẹ̀lé e, òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

12 OLUWA ranti wa, yóo bukun wa, yóo bukun ilé Israẹli, yóo bukun ìdílé Aaroni.

13 Yóo bukun àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ati àwọn ọlọ́lá ati àwọn mẹ̀kúnnù.

14 OLUWA yóo jẹ́ kí ẹ máa bí sí i, àtẹ̀yin àtàwọn ọmọ yín.

15 Kí OLUWA tí ó dá ọ̀run ati ayé bukun yín!

16 OLUWA ló ni ọ̀run, ṣugbọn ó fi ayé fún àwọn eniyan.

17 Àwọn òkú kò lè yin OLUWA, àní àwọn tí wọ́n ti dákẹ́ ninu ibojì.

18 Ṣugbọn àwa yóo máa yin OLUWA, láti ìsinsìnyìí lọ, ati títí laelae. Ẹ máa yin OLUWA.

116

1 Mo fẹ́ràn OLUWA nítorí pé ó gbọ́ adura ati ẹ̀bẹ̀ mi.

2 Nítorí pé ó tẹ́tí sí mi, nítorí náà, n óo máa ké pè é níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láàyè.

3 Tàkúté ikú yí mi ká; ìrora isà òkú dé bá mi; ìyọnu ati ìnira sì bò mí mọ́lẹ̀.

4 Nígbà náà ni mo ké pe OLUWA, mo ní, “OLUWA, mo bẹ̀ ọ́, gbà mí!”

5 Olóore ọ̀fẹ́ ati olódodo ni OLUWA, aláàánú ni Ọlọrun wa.

6 OLUWA a máa pa àwọn onírẹ̀lẹ̀ mọ́; nígbà tí a rẹ̀ mí sílẹ̀, ó gbà mí.

7 Sinmi ìwọ ọkàn mi, bíi ti àtẹ̀yìnwá, nítorí pé OLUWA ṣeun fún ọ lọpọlọpọ.

8 Nítorí ìwọ OLUWA ti gba ọkàn mi lọ́wọ́ ikú, o gba ojú mi lọ́wọ́ omijé, o sì gba ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú.

9 Mò ń rìn níwájú OLUWA, lórí ilẹ̀ alààyè.

10 Igbagbọ mi kò yẹ̀, nígbà tí mo tilẹ̀ wí pé, “Ìpọ́njú dé bá mi gidigidi.”

11 Mo wí ninu ìdààmú ọkàn pé, “Èké ni gbogbo eniyan.”

12 Kí ni n óo san fún OLUWA, nítorí gbogbo oore rẹ̀ lórí mi?

13 N óo mu ẹbọ nǹkan mímu wá fún OLUWA, n óo sì pe orúkọ rẹ̀.

14 N óo san ẹ̀jẹ́ mi fún OLUWA, lójú gbogbo àwọn eniyan rẹ̀.

15 Iyebíye ni ikú àwọn eniyan rẹ̀ mímọ́ lójú OLUWA.

16 OLUWA, iranṣẹ rẹ ni mo jẹ́, iranṣẹ rẹ ni mo jẹ́, àní, ọmọ iranṣẹbinrin rẹ. O ti tú ìdè mi.

17 N óo rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ, n óo sì pe orúkọ rẹ OLUWA.

18 N óo san ẹ̀jẹ́ mi fún OLUWA lójú gbogbo àwọn eniyan rẹ̀,

19 ninu àgbàlá ilé OLUWA, láàrin rẹ, ìwọ ìlú Jerusalẹmu. Ẹ máa yin OLUWA!

117

1 Ẹ máa yin OLUWA, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè! Ẹ yìn ín gbogbo ẹ̀yin eniyan,

2 Nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ tóbi sí wa, òtítọ́ rẹ̀ sì wà títí laelae. Ẹ máa yin OLUWA.

118

1 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé, “Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

3 Kí àwọn ará ilé Aaroni wí pé, “Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

4 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA wí pé, “Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

5 Ninu ìpọ́njú, mo ké pe OLUWA, ó dá mi lóhùn, ó sì tú mi sílẹ̀.

6 Nígbà tí OLUWA wà pẹlu mi, ẹ̀rù kò bà mí. Kí ni eniyan lè fi mí ṣe?

7 OLUWA wà pẹlu mi láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí náà, n óo wo àwọn tí wọ́n kórìíra mi pẹlu ayọ̀ ìṣẹ́gun.

8 Ó sàn láti sá di OLUWA, ju ati gbẹ́kẹ̀lé eniyan lọ.

9 Ó sàn láti sá di OLUWA, ju ati gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìjòyè.

10 Gbogbo orílẹ̀-èdè dòòyì ká mi, ṣugbọn ní orúkọ OLUWA, mo pa wọ́n run!

11 Wọ́n yí mi ká, àní, wọ́n dòòyì ká mi, ṣugbọn ni orúkọ OLUWA, mo pa wọ́n run!

12 Wọ́n ṣùrù bò mí bí oyin, ṣugbọn kíá ni wọ́n kú bí iná ìṣẹ́pẹ́; ní orúkọ OLUWA, mo pa wọ́n run.

13 Wọ́n gbógun tì mí gidigidi, tóbẹ́ẹ̀ tí mo fẹ́rẹ̀ ṣubú, ṣugbọn OLUWA ràn mí lọ́wọ́.

14 OLUWA ni agbára ati orin mi, ó ti di olùgbàlà mi.

15 Ẹ gbọ́ orin ayọ̀ ìṣẹ́gun, ninu àgọ́ àwọn olódodo. “Ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ti ṣe iṣẹ́ agbára ńlá.

16 A gbé ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ga, ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ti ṣe iṣẹ́ agbára ńlá!”

17 N ò ní kú, yíyè ni n óo yè, n óo sì máa fọnrere nǹkan tí OLUWA ṣe.

18 OLUWA jẹ mí níyà pupọ, ṣugbọn kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.

19 Ṣí ìlẹ̀kùn òdodo fún mi, kí n lè gba ibẹ̀ wọlé, kí n sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA.

20 Èyí ni ẹnu ọ̀nà OLUWA; àwọn olódodo yóo gba ibẹ̀ wọlé.

21 Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí pé o gbọ́ ohùn mi, o sì ti di olùgbàlà mi.

22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀, ni ó di pataki igun ilé.

23 OLUWA ló ṣe èyí; ó sì jẹ́ ohun ìyanu lójú wa.

24 Òní ni ọjọ́ tí OLUWA dá, ẹ jẹ́ kí á máa yọ̀, kí inú wa sì máa dùn.

25 OLUWA, à ń bẹ̀ ọ́, gbà wá, OLUWA, à ń bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí á ṣe àṣeyege.

26 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ OLUWA, láti inú ilé rẹ ni a ti ń yìn ọ́, OLUWA.

27 OLUWA ni Ọlọrun, ó sì ti tan ìmọ́lẹ̀ sí wa. Pẹlu ẹ̀ka igi lọ́wọ́, ẹ bẹ̀rẹ̀ ayẹyẹ ìwọ́de ẹbọ náà, títí dé ibi ìwo pẹpẹ.

28 Ìwọ ni Ọlọrun mi, n óo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ. Ìwọ ni Ọlọrun mi, n óo máa gbé ọ ga.

29 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

119

1 Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ìgbé ayé wọn kò lábàwọ́n, àní àwọn tí ń rìn gẹ́gẹ́ bí òfin OLUWA.

2 Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí wọn ń fi tọkàntọkàn ṣe ìfẹ́ rẹ̀.

3 Àwọn tí wọn kò dẹ́ṣẹ̀, ṣugbọn tí wọn ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

4 O ti pàṣẹ pé kí á fi tọkàntọkàn pa òfin rẹ mọ́,

5 Ìbá ti dára tó tí mo bá lè dúró ṣinṣin ninu ìlànà rẹ!

6 Òun ni ojú kò fi ní tì mí, nítorí pé òfin rẹ ni mò ń tẹ̀lé.

7 N óo yìn ọ́ pẹlu inú mímọ́, bí mo ṣe ń kọ́ ìlànà òdodo rẹ.

8 N óo máa pa òfin rẹ mọ́, má kọ̀ mí sílẹ̀ patapata.

9 Báwo ni ọdọmọkunrin ṣe lè mú kí ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Nípa títẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ ni.

10 Tọkàntọkàn ni mo fi ń ṣe ìfẹ́ rẹ, má jẹ́ kí n ṣìnà kúrò ninu òfin rẹ.

11 Mo ti fi ọ̀rọ̀ rẹ sọ́kàn, kí n má baà ṣẹ̀ ọ́.

12 Ìyìn ni fún ọ, OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ!

13 Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa.

14 Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́, bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

15 N óo máa ṣe àṣàrò ninu òfin rẹ, n óo sì kọjú sí ọ̀nà rẹ.

16 N óo láyọ̀ ninu àwọn ìlànà rẹ, n kò ní gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

17 Ṣe ọpọlọpọ oore fún èmi iranṣẹ rẹ, kí n lè wà láàyè, kí n sì máa tẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

18 Là mí lójú, kí n lè rí àwọn nǹkan ìyanu tí ó wà ninu òfin rẹ.

19 Àlejò ni mí láyé, má fi òfin rẹ pamọ́ fún mi.

20 Òùngbẹ títẹ̀lé òfin rẹ ń gbẹ ọkàn mi, nígbà gbogbo.

21 O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún, tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́.

22 Mú ẹ̀gàn ati àbùkù wọn kúrò lára mi, nítorí pé mo ti pa òfin rẹ mọ́.

23 Bí àwọn ìjòyè tilẹ̀ gbìmọ̀ràn ọ̀tẹ̀ nítorí mi, sibẹ, èmi iranṣẹ rẹ yóo ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.

24 Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi, àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.

25 Mo di ẹni ilẹ̀, sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

26 Nígbà tí mo jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe mi, o dá mi lóhùn; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

27 La òfin rẹ yé mi, n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí iṣẹ́ ìyanu rẹ.

28 Ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi nítorí ìbànújẹ́, mú mi lọ́kàn le gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

29 Mú ìwà èké jìnnà sí mi, kí o sì fi oore ọ̀fẹ́ kọ́ mi ní òfin rẹ.

30 Mo ti yan ọ̀nà òtítọ́, mo ti fi ọkàn sí òfin rẹ.

31 Mo pa òfin rẹ mọ́, OLUWA, má jẹ́ kí ojú ó tì mí.

32 N óo yára láti pa òfin rẹ mọ́, nígbà tí o bá mú òye mi jinlẹ̀ sí i.

33 OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ, n óo sì pa wọ́n mọ́ dé òpin.

34 Là mí lóye, kí n lè máa pa òfin rẹ mọ́, kí n sì máa fi tọkàntọkàn pa wọ́n mọ́.

35 Tọ́ mi sí ọ̀nà nípa òfin rẹ, nítorí pé mo láyọ̀ ninu rẹ̀.

36 Mú kí ọkàn mi fà sí òfin rẹ, kí ó má fà sí ọrọ̀ ayé.

37 Yí ojú mi kúrò ninu wíwo nǹkan asán, sọ mí di alààyè ní ọ̀nà rẹ.

38 Mú ìlérí rẹ ṣẹ fún iranṣẹ rẹ, àní, ìlérí tí o ṣe fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ.

39 Mú ẹ̀gàn tí ń bà mí lẹ́rù kúrò, nítorí pé ìlànà rẹ dára.

40 Wò ó, ọkàn mi fà sí ati máa tẹ̀lé ìlànà rẹ, sọ mí di alààyè nítorí òdodo rẹ!

41 Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn mí, OLÚWA, kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

42 Nígbà náà ni n óo lè dá àwọn tí ń gàn mí lóhùn, nítorí mo gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

43 Má gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ rẹ lẹ́nu mi rárá, nítorí ìrètí mi ń bẹ ninu ìlànà rẹ.

44 N óo máa pa òfin rẹ mọ́ nígbà gbogbo, lae ati laelae.

45 N óo máa rìn fàlàlà, nítorí pé mo tẹ̀lé ìlànà rẹ.

46 N óo máa sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba, ojú kò sì ní tì mí.

47 Mo láyọ̀ ninu òfin rẹ, nítorí tí mo fẹ́ràn rẹ̀.

48 Mo bọ̀wọ̀ fún àṣẹ rẹ tí mo fẹ́ràn, n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.

49 Ranti ọ̀rọ̀ tí o bá èmi iranṣẹ rẹ sọ, èyí tí ó fún mi ní ìrètí.

50 Ohun tí ó ń tù mí ninu ní àkókò ìpọ́njú ni pé: ìlérí rẹ mú mi wà láàyè.

51 Àwọn onigbeeraga ń kẹ́gàn mi gidigidi, ṣugbọn n ò kọ òfin rẹ sílẹ̀.

52 Mo ranti òfin rẹ àtijọ́, OLUWA, ọkàn mi sì balẹ̀.

53 Inú mi á máa ru, nígbà tí mo bá rí àwọn eniyan burúkú, tí wọn ń rú òfin rẹ.

54 Òfin rẹ ni mò ń fi ń ṣe orin kọ, lákòókò ìrìn àjò mi láyé.

55 Mo ranti orúkọ rẹ lóru; OLUWA, mo sì pa òfin rẹ mọ́:

56 Èyí ni ìṣe mi: Èmi a máa pa òfin rẹ mọ́.

57 OLUWA, ìwọ nìkan ni mo ní; mo ṣe ìlérí láti pa òfin rẹ mọ́.

58 Tọkàntọkàn ni mò ń wá ojurere rẹ, ṣe mí lóore gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

59 Nígbà tí mo ronú nípa ìṣe mi, mo yipada sí ìlànà rẹ;

60 mo yára, bẹ́ẹ̀ ni n kò lọ́ra láti pa òfin rẹ mọ́.

61 Bí okùn àwọn eniyan burúkú tilẹ̀ wé mọ́ mi, n kò ní gbàgbé òfin rẹ.

62 Mo dìde lọ́gànjọ́ láti yìn ọ́, nítorí ìlànà òdodo rẹ.

63 Ọ̀rẹ́ gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ ni mí, àní, àwọn tí wọn ń pa òfin rẹ mọ́.

64 OLUWA, ayé kún fún ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

65 OLUWA, o ti ṣeun fún èmi iranṣẹ rẹ, gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

66 Fún mi ní òye ati ìmọ̀ pípé, nítorí mo ní igbagbọ ninu àṣẹ rẹ.

67 Kí o tó jẹ mí níyà, mo yapa kúrò ninu òfin rẹ; ṣugbọn nisinsinyii, mò ń mú àṣẹ rẹ ṣẹ.

68 OLUWA rere ni ọ́, rere ni o sì ń ṣe; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

69 Àwọn onigbeeraga ti wé irọ́ mọ́ mi lẹ́sẹ̀, ṣugbọn èmi fi tọkàntọkàn pa òfin rẹ mọ́.

70 Ọkàn wọn ti yigbì, ṣugbọn èmi láyọ̀ ninu òfin rẹ.

71 Ìpọ́njú tí mo rí ṣe mí ní anfaani, ó mú kí n kọ́ nípa ìlànà rẹ.

72 Òfin rẹ níye lórí fún mi, ó ju ẹgbẹẹgbẹrun wúrà ati fadaka lọ.

73 Ìwọ ni o mọ mí, ìwọ ni o dá mi, fún mi ní òye kí n lè kọ́ òfin rẹ.

74 Inú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yóo máa dùn nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí pé mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

75 OLUWA, mo mọ̀ pé ìdájọ́ rẹ tọ̀nà, ati pé lórí ẹ̀tọ́ ni o pọ́n mi lójú.

76 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ máa tù mí ninu, gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí o ṣe fún èmi, iranṣẹ rẹ.

77 Ṣàánú mi, kí n lè wà láàyè, nítorí pé òfin rẹ ni ìdùnnú mi.

78 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn onigbeeraga, nítorí wọ́n ṣe àrékérekè sí mi láìnídìí; ní tèmi, n óo máa ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

79 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ tọ̀ mí wá, kí wọ́n lè mọ òfin rẹ.

80 Níti pípa òfin rẹ mọ́, jẹ́ kí n pé, kí ojú má baà tì mí.

81 Mo wá ìgbàlà rẹ títí, àárẹ̀ mú ọkàn mi; ṣugbọn mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

82 Mo fojú sọ́nà títí, agara dá mi, níbi tí mo tí ń retí ìmúṣẹ ìlérí rẹ. Mo ní, “Nígbà wo ni o óo tù mí ninu?”

83 Mo dàbí agbè ọtí tí ó ti di àlòpatì, sibẹ, n kò gbàgbé ìlànà rẹ.

84 Èmi iranṣẹ rẹ yóo ti dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ óo dájọ́ fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi?

85 Àwọn onigbeeraga ti gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí, àní, àwọn tí kì í pa òfin rẹ mọ́.

86 Gbogbo òfin rẹ ló dájú; ràn mí lọ́wọ́, nítorí wọ́n ń fi ìwà èké ṣe inúnibíni mi.

87 Wọ́n fẹ́rẹ̀ pa mí run láyé, ṣugbọn n kò kọ ìlànà rẹ sílẹ̀.

88 Dá ẹ̀mí mi sí gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, kí n lè máa mú gbogbo àṣẹ rẹ ṣẹ.

89 OLUWA, títí lae ni ọ̀rọ̀ rẹ fìdí múlẹ̀ lọ́run.

90 Òtítọ́ rẹ wà láti ìrandíran; o ti fi ìdí ayé múlẹ̀, ó sì dúró.

91 Ohun gbogbo wà gẹ́gẹ́ bí ìlànà rẹ, títí di òní, nítorí pé iranṣẹ rẹ ni gbogbo wọn.

92 Bí kò bá jẹ́ pé òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi, ǹ bá ti ṣègbé ninu ìpọ́njú.

93 Lae, n kò ní gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ, nítorí pé, nípasẹ̀ wọn ni o fi mú mi wà láyé.

94 Ìwọ ni o ni mí, gbà mí; nítorí pé mo ti kọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.

95 Àwọn eniyan burúkú ba dè mí, wọ́n fẹ́ pa mí run, ṣugbọn mò ń ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

96 Mo ti rí i pé kò sí ohun tí ó lè pé tán, àfi òfin rẹ nìkan ni kò lópin.

97 Mo fẹ́ràn òfin rẹ lọpọlọpọ! Òun ni mo fi ń ṣe àṣàrò tọ̀sán-tòru.

98 Ìlànà rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí pé òun ni ó ń darí mi nígbà gbogbo.

99 Òye mi ju ti àwọn olùkọ́ mi lọ, nítorí pé ìlànà rẹ ni mo fi ń ṣe àṣàrò.

100 Òye mi ju ti àwọn àgbà lọ, nítorí pé mo gba ẹ̀kọ́ rẹ."

101 N kò rin ọ̀nà ibi kankan, kí n lè pa òfin rẹ mọ́.

102 N kò yapa kúrò ninu òfin rẹ, nítorí pé o ti kọ́ mi.

103 Ọ̀rọ̀ rẹ dùn mọ́ mi pupọ, ó dùn ju oyin lọ.

104 Nípa ẹ̀kọ́ rẹ ni mo fi ní òye, nítorí náà mo kórìíra gbogbo ìwà èké.

105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni àtùpà fún ẹsẹ̀ mi, òun ni ìmọ́lẹ̀ sí ọ̀nà mi.

106 Mo ti búra, n óo sì mú un ṣẹ, pé n óo máa pa òfin òdodo rẹ mọ́.

107 Ojú ń pọ́n mi lọpọlọpọ, sọ mí di alààyè, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

108 Gba ẹbọ ìyìn àtọkànwá mi, OLUWA, kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

109 Ayé mi wà ninu ewu nígbà gbogbo, ṣugbọn n kò gbàgbé òfin rẹ.

110 Àwọn eniyan burúkú ti dẹ okùn sílẹ̀ dè mí, ṣugbọn n kò kọ ìlànà rẹ sílẹ̀.

111 Ìlànà rẹ ni ogún mi títí lae, nítorí pé òun ni ayọ̀ mi.

112 Mo ti pinnu láti máa tẹ̀lé ìlànà rẹ nígbà gbogbo, àní, títí dé òpin.

113 Mo kórìíra àwọn oníyèméjì, ṣugbọn mo fẹ́ràn òfin rẹ.

114 Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi ati asà mi, mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin aṣebi, kí n lè pa òfin Ọlọrun mi mọ́.

116 Gbé mi ró gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, kí n lè wà láàyè, má sì dójú ìrètí mi tì mí.

117 Gbé mi ró, kí n lè wà láìléwu, kí n lè máa ka ìlànà rẹ sí nígbà gbogbo.

118 O ti kọ gbogbo àwọn tí ó yapa kúrò ninu ìlànà rẹ sílẹ̀, nítorí pé asán ni gbogbo ẹ̀tàn wọn.

119 O ti pa àwọn eniyan burúkú tì, bí ìdàrọ́ irin, nítorí náà ni mo ṣe fẹ́ràn ìlànà rẹ.

120 Mo wárìrì nítorí pé mo bẹ̀rù rẹ, mo sì bẹ̀rù ìdájọ́ rẹ.

121 Mo ti ṣe ohun tí ó tọ́ tí ó sì yẹ, má fi mí sílẹ̀ fún àwọn tí wọn ń ni mí lára.

122 Ṣe ìlérí ìrànlọ́wọ́ fún ire èmi iranṣẹ rẹ, má sì jẹ́ kí àwọn onigbeeraga ni mí lára.

123 Mo fojú sọ́nà títí, agara dá mi, níbi tí mo tí ń retí ìgbàlà rẹ, ati ìmúṣẹ ìlérí òdodo rẹ.

124 Ṣe sí èmi iranṣẹ rẹ, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

125 Iranṣẹ rẹ ni mí, fún mi lóye, kí n lè mọ ìlànà rẹ.

126 OLUWA, ó tó àkókò fún ọ láti ṣe nǹkankan, nítorí àwọn eniyan ń rú òfin rẹ.

127 Nítorí náà ni èmi ṣe fẹ́ràn òfin rẹ ju wúrà lọ; àní, ju ojúlówó wúrà.

128 Nítorí náà, èmi ń tẹ̀lé gbogbo ẹ̀kọ́ rẹ, mo sì kórìíra gbogbo ọ̀nà èké.

129 Òfin rẹ dára, nítorí náà ni mo ṣe ń pa wọ́n mọ́.

130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ a máa fúnni ní ìmọ́lẹ̀, a sì máa fi òye fún àwọn onírẹ̀lẹ̀.

131 Mo la ẹnu, mò ń mí hẹlẹ, nítorí pé mò ń lépa òfin rẹ.

132 Kọjú sí mi kí o ṣe mí lóore bí o ti máa ń ṣe sí àwọn tí ó fẹ́ràn rẹ.

133 Mú ẹsẹ̀ mi dúró gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, má sì jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ kankan jọba lórí mi.

134 Gbà mí lọ́wọ́ ìnilára àwọn eniyan, kí n lè máa tẹ̀lé ìlànà rẹ.

135 Jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí ara èmi iranṣẹ rẹ; kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

136 Omijé ń dà lójú mi pòròpòrò, nítorí pé àwọn eniyan kò pa òfin rẹ mọ́.

137 Olódodo ni ọ́, OLUWA, ìdájọ́ rẹ sì tọ́.

138 Òdodo ni o fi pa àṣẹ rẹ, òtítọ́ patapata ni.

139 Mò ń tara gidigidi, nítorí pé àwọn ọ̀tá mi gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

140 A ti yẹ ọ̀rọ̀ rẹ wò fínnífínní, ó dúró ṣinṣin, mo sì fẹ́ràn rẹ̀.

141 Bí mo tilẹ̀ kéré, tí ayé sì kẹ́gàn mi, sibẹ n kò gbàgbé ìlànà rẹ.

142 Òdodo rẹ wà títí lae, òtítọ́ sì ni òfin rẹ.

143 Ìyọnu ati ìpayà dé bá mi, ṣugbọn mo láyọ̀ ninu òfin rẹ.

144 Òdodo ni ìlànà rẹ títí lae, fún mi ní òye kí n lè wà láàyè.

145 Tọkàntọkàn ni mo fi ń ké pè ọ́, OLUWA, dá mi lóhùn; n óo sì máa tẹ̀lé ìlànà rẹ.

146 Mo ké pè ọ́; gbà mí, n óo sì máa mú àṣẹ rẹ ṣẹ.

147 Mo jí ní òwúrọ̀ kutukutu, mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́; mò ń retí ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ rẹ.

148 N kò fi ojú ba oorun ní gbogbo òru, kí n lè máa ṣe àṣàrò lórí ọ̀rọ̀ rẹ.

149 Gbóhùn mi nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, OLÚWA, dá mi sí nítorí òtítọ́ rẹ.

150 Àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi súnmọ́ tòsí; wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.

151 Ṣugbọn ìwọ wà nítòsí, OLUWA, òtítọ́ sì ni gbogbo òfin rẹ.

152 Ó pẹ́ tí mo ti kọ́ ninu ìlànà rẹ, pé o ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

153 Wo ìpọ́njú mi, kí o gbà mí, nítorí n kò gbàgbé òfin rẹ.

154 Gba ẹjọ́ mi rò, kí o sì gbà mí, sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn eniyan burúkú, nítorí wọn kò wá ìlànà rẹ.

156 Àánú rẹ pọ̀, OLUWA, sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ rẹ.

157 Àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi ati àwọn ọ̀tá mi pọ̀, ṣugbọn n kò yapa kúrò ninu ìlànà rẹ.

158 Mò ń wo àwọn ọ̀dàlẹ̀ pẹlu ìríra, nítorí wọn kì í pa òfin rẹ mọ́.

159 Wo bí mo ti fẹ́ ẹ̀kọ́ rẹ tó! Dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ, gbogbo òfin òdodo rẹ ni yóo máa wà títí lae.

161 Àwọn ìjòyè ń ṣe inúnibíni mi láìnídìí, ṣugbọn mo bẹ̀rù ọ̀rọ̀ rẹ tọkàntọkàn.

162 Mo láyọ̀ ninu ọ̀rọ̀ rẹ, bí ẹni pé mo ní ọpọlọpọ ìkógun.

163 Mo kórìíra èké ṣíṣe, ara mi kọ̀ ọ́, ṣugbọn mo fẹ́ràn òfin rẹ.

164 Nígbà meje lojoojumọ ni mò ń yìn ọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.

165 Alaafia ńláńlá ń bẹ fún àwọn tí ó fẹ́ràn òfin rẹ, kò sí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.

166 Mò ń retí ìgbàlà rẹ, OLUWA, mo sì ń pa àwọn òfin rẹ mọ́.

167 Mò ń pa àṣẹ rẹ mọ́, mo fẹ́ràn wọn gidigidi.

168 Mo gba ẹ̀kọ́ rẹ, mo sì ń tẹ̀lé ìlànà rẹ; gbogbo ìṣe mi ni ò ń rí.

169 Jẹ́ kí igbe mi dé ọ̀dọ̀ rẹ, OLUWA, fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi dé iwájú rẹ, kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

171 Ẹnu mi yóo kún fún ìyìn rẹ, pé o ti kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

172 N óo máa fi ọ̀rọ̀ rẹ ṣe orin kọ, nítorí pé gbogbo òfin rẹ ni ó tọ̀nà.

173 Múra láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí pé mo ti gba ẹ̀kọ́ rẹ.

174 Ọkàn mi ń fà sí ìgbàlà rẹ, OLUWA; òfin rẹ sì ni inú dídùn mi.

175 Dá mi sí kí n lè máa yìn ọ́, sì jẹ́ kí òfin rẹ ràn mí lọ́wọ́.

176 Mo ti ṣìnà bí aguntan tó sọnù; wá èmi, iranṣẹ rẹ, rí, nítorí pé n kò gbàgbé òfin rẹ.

120

1 OLUWA ni mo ké pè, nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú, ó sì dá mi lóhùn.

2 OLUWA, gbà mí lọ́wọ́ àwọn èké, ati lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́tàn.

3 Kí ni a óo fi san án fun yín? Kí ni a óo sì ṣe si yín, ẹ̀yin ẹlẹ́tàn?

4 Ọfà mímú ni a óo ta yín, a óo sì dáná sun yín.

5 Mo gbé! Nítorí pé mo dàbí àlejò tó wọ̀ ní Meṣeki, tí ń gbé ààrin àwọn àgọ́ Kedari.

6 Ó pẹ́ jù tí mo tí ń bá àwọn tí ó kórìíra alaafia gbé.

7 Alaafia ni èmi fẹ́, ṣugbọn nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ìjà ṣá ni tiwọn.

121

1 Mo gbójú sókè wo àwọn òkè, níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi ti ń wá?

2 Ìrànlọ́wọ́ mi ń ti ọ̀dọ̀ OLUWA wá, ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.

3 Kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ ó yẹ̀, ẹni tí ń pa ọ́ mọ́ kò ní tòògbé.

4 Wò ó, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́ kò ní tòògbé, bẹ́ẹ̀ ni kò ní sùn.

5 OLUWA ni olùpamọ́ rẹ. OLUWA yóo ṣíji bò ọ́ ní apá ọ̀tún rẹ.

6 Oòrùn kò ní ṣe ọ́ léṣe lọ́sàn-án, bẹ́ẹ̀ ni òṣùpá kò ní pa ọ́ lára lóru.

7 OLUWA óo dáàbò bò ọ́ lọ́wọ́ gbogbo ibi, yóo pa ọ́ mọ́.

8 OLUWA yóo pa àlọ ati ààbọ̀ rẹ mọ́, láti ìsinsìnyìí lọ ati títí lae.

122

1 Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ilé OLUWA.”

2 A ti tẹsẹ̀ bọ inú ìgboro rẹ, Jerusalẹmu.

3 Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí a kọ́, tí gbogbo rẹ̀ já pọ̀ di ọ̀kan.

4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà, àní, àwọn ẹ̀yà eniyan OLUWA máa ń gòkè lọ, láti dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí a pa fún Israẹli.

5 Níbẹ̀ ni a tẹ́ ìtẹ́ ìdájọ́ sí, àní, ìtẹ́ ìdájọ́ àwọn ọba ìdílé Dafidi.

6 Gbadura fún alaafia Jerusalẹmu! “Yóo dára fún àwọn tí ó fẹ́ràn rẹ!

7 Kí alaafia ó wà ninu rẹ, kí ìbàlẹ̀ àyà wà ninu ilé ìṣọ́ rẹ.”

8 Nítorí ti àwọn ará ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi, n óo wí pé, “Kí alaafia ó wà ninu rẹ.”

9 Nítorí ti ilé OLUWA, Ọlọrun wa, èmi óo máa wá ire rẹ.

123

1 Ìwọ ni mo gbé ojú sókè sí, ìwọ tí o gúnwà ní ọ̀run.

2 Wò ó, bí iranṣẹkunrin ti máa ń wo ojú oluwa rẹ̀, tí iranṣẹbinrin sì máa ń wo ojú oluwa rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni à ń wo ojú OLUWA, Ọlọrun wa, títí tí yóo fi ṣàánú wa.

3 Ṣàánú wa, OLUWA, ṣàánú wa, ẹ̀gàn yìí ti pọ̀ jù!

4 Ẹ̀gàn àwọn onírera ti pọ̀ jù fún wa; yẹ̀yẹ́ àwọn onigbeeraga sì ti sú wa.

124

1 Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa, ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ wí pé,

2 “Tí kì í bá ṣe pé OLUWA tí ó wà lẹ́yìn wa nígbà tí ọmọ aráyé gbógun tì wá,

3 wọn ìbá gbé wa mì láàyè, nígbà tí inú bí wọn sí wa;

4 àgbàrá ìbá ti gbá wa lọ, ìṣàn omi ìbá ti bò wá mọ́lẹ̀;

5 ìgbì omi ìbá ti gbé wa mì.”

6 Ọpẹ́ ni fún OLUWA, tí kò fi wá ṣe ẹran ìjẹ fún wọn.

7 A ti yọ, bí ẹyẹ tí ó yọ ninu okùn apẹyẹ: okùn ti já; àwa sì ti yọ.

8 Ọ̀dọ̀ OLUWA ni ìrànlọ́wọ́ wa ti wá, ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.

125

1 Àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA dàbí òkè Sioni, tí ẹnikẹ́ni kò lè ṣí nídìí, ṣugbọn tí ó wà títí lae.

2 Bí òkè ńlá ti yí Jerusalẹmu ká, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA yí àwọn eniyan rẹ̀ ká, láti ìsinsìnyìí lọ ati títí lae.

3 Eniyan burúkú kò ní ní àṣẹ lórí ilẹ̀ àwọn olódodo, kí àwọn olódodo má baà dáwọ́ lé ibi.

4 OLUWA, ṣe oore fún àwọn eniyan rere, ati fún àwọn olódodo.

5 Ṣugbọn OLUWA yóo fi irú ìyà àwọn aṣebi jẹ àwọn tí ó yà sí ọ̀nà àìtọ́. Alaafia fún Israẹli!

126

1 Nígbà tí OLUWA kó àwọn ìgbèkùn Sioni pada, ó dàbí àlá lójú wa.

2 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ wa kún fún ẹ̀rín, a sì kọrin ayọ̀, nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù ń wí pé, “OLUWA mà ṣe nǹkan ńlá fún àwọn eniyan yìí!”

3 Lóòótọ́, OLUWA ṣe nǹkan ńlá fún wa, nítorí náà à ń yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀.

4 Dá ire wa pada, OLUWA, bí ìṣàn omi ní ipadò aṣálẹ̀ Nẹgẹbu.

5 Àwọn tí ń fọ́n irúgbìn pẹlu omi lójú, jẹ́ kí wọn kórè rẹ̀ tayọ̀tayọ̀.

6 Ẹni tí ń gbé irúgbìn lọ sí oko tẹkúntẹkún, yóo ru ìtí ọkà pada sílé tayọ̀tayọ̀.

127

1 Bí OLUWA kò bá kọ́ ilé, asán ni wahala àwọn tí ń kọ́ ọ. Bí OLUWA kò bá ṣọ́ ìlú, asán ni àìsùn àwọn aṣọ́de.

2 Asán ni kí á jí ní òwúrọ̀ kutukutu, kí á tún pẹ́ títí kí á tó sùn. Asán ni kí á máa fi làálàá wá oúnjẹ; nítorí pé OLUWA a máa fún àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ ní oorun sùn.

3 Wò ó! Ẹ̀bùn OLUWA ni ọmọ; òun ní fi oyún inú ṣìkẹ́ eniyan.

4 Bí ọfà ti rí lọ́wọ́ jagunjagun, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ ìgbà òwúrọ̀ ẹni.

5 Ayọ̀ ń bẹ fun ẹni tí apó rẹ̀ kún fún wọn. Ojú kò ní tì í nígbà tí ó bá ń bá àwọn ọ̀tá rẹ̀ rojọ́ lẹ́nu bodè.

128

1 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bẹ̀rù OLÚWA, tí ó sì ń tẹ̀lé ìlànà rẹ̀.

2 O óo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, ayọ̀ ń bẹ fún ọ, yóo sì dára fún ọ.

3 Aya rẹ yóo dàbí àjàrà eléso pupọ ninu ilé rẹ; bí ọmọ tií yí igi olifi ká, ni àwọn ọmọ rẹ yóo yí tabili oúnjẹ rẹ ká.

4 Wò ó, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA yóo kẹ́ ẹni tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

5 Kí OLUWA bukun ọ láti Sioni! Kí o máa rí ire Jerusalẹmu ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.

6 Kí o máa rí arọmọdọmọ rẹ. Kí alaafia máa wà ní Israẹli.

129

1 Ọpọlọpọ ìgbà ni wọ́n ti ń pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi. Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ wí pé,

2 “Ọpọlọpọ ìgbà ni wọ́n ti ń pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi, sibẹ, wọn kò borí mi.”

3 Wọ́n to ẹgba sí mi lẹ́yìn, gbogbo ẹ̀yìn mi lé bíi poro oko.

4 Ṣugbọn olódodo ni OLUWA, ó ti gé okùn àwọn eniyan burúkú.

5 Ojú yóo ti gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni, a óo lé wọn pada sẹ́yìn.

6 Wọn óo dàbí koríko tí ó hù lórí òrùlé, tí kì í dàgbà kí ó tó gbẹ.

7 Kò lè kún ọwọ́ ẹni tí ń pa koríko; kò sì lè kún ọwọ́ ẹni tí ń di koríko ní ìtí.

8 Àwọn èrò ọ̀nà kò sì ní kí ẹni tí ń gé e pé: “OLUWA óo fèrè síṣẹ́ o! Ẹ kúuṣẹ́, OLUWA óo fèrè sí i.”

130

1 Ninu ìṣòro ńlá ni mò ń ké pè ọ́, OLUWA!

2 OLUWA, gbóhùn mi, dẹtí sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

3 Bí OLUWA bá ń sàmì ẹ̀ṣẹ̀, ta ló lè yege?

4 Ṣugbọn ní ìkáwọ́ rẹ ni ìdáríjì wà, kí á lè máa bẹ̀rù rẹ.

5 Mo gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, àní, mo gbé ọkàn mi lé e, mo sì ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ̀.

6 Mò ń retí rẹ, OLUWA, ju bí àwọn aṣọ́de ti máa ń retí kí ilẹ̀ mọ́ lọ, àní, ju bí àwọn aṣọ́de, ti máa ń retí pé kí ilẹ̀ mọ́.

7 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ ní ìrètí ninu OLUWA! Nítorí pé ní ìkáwọ́ rẹ̀ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ wà, ní ìkáwọ́ rẹ̀ sì ni ìràpadà kíkún wà.

8 Òun óo sì ra Israẹli pada kúrò ninu gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

131

1 OLUWA, n kò ṣe ìgbéraga, bẹ́ẹ̀ ni ojú mi kò gbé sókè. N ò dáwọ́ lé nǹkan ńláńlá, n ò sì dá àrà tí ó jù mí lọ.

2 Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi lọ́kàn balẹ̀, mo dákẹ́ jẹ́ẹ́, bí ọmọ ọwọ́ tíí dákẹ́ jẹ́ẹ́ láyà ìyá rẹ̀. Ọkàn mi balẹ̀ bíi ti ọmọ ọwọ́ tó dákẹ́ jẹ́ẹ́.

3 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ ní ìrètí ninu OLUWA, láti ìsinsìnyìí lọ ati títí laelae.

132

1 OLUWA, ranti gbogbo ìyà tí Dafidi fara dà.

2 Ranti bí ó ṣe búra fún OLUWA, tí ó sì jẹ́jẹ̀ẹ́ fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu,

3 tí ó ní, “N kò ní wọ inú ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní bọ́ sí orí ibùsùn mi;

4 n kò ní sùn, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní tòògbé,

5 títí tí n óo fi wá ààyè fún OLUWA, àní, tí n óo fi pèsè ibùgbé fún ìwọ Alágbára, Ọlọrun Jakọbu.”

6 A gbúròó rẹ̀ ní Efurata, a rí i ní oko Jearimu.

7 “Ẹ jẹ́ kí á lọ sí ibùgbé rẹ̀; ẹ jẹ́ kí á lọ wólẹ̀ níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.”

8 Dìde, OLUWA, lọ sí ibi ìsinmi rẹ, tìwọ ti àpótí agbára rẹ.

9 Jẹ́ kí àwọn alufaa rẹ wọ ẹ̀wù òdodo, kí àwọn eniyan mímọ́ rẹ sì máa kọrin ayọ̀.

10 Nítorí ti Dafidi, iranṣẹ rẹ, má jẹ́ kí ẹni tí a fi òróró rẹ yàn yíjú kúrò lára rẹ.

11 OLUWA ti ṣe ìbúra tí ó dájú fún Dafidi, èyí tí kò ní yipada; ó ní, “Ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹ ni n óo gbé ka orí ìtẹ́ rẹ.

12 Bí àwọn ọmọ rẹ bá pa majẹmu mi mọ́, tí wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí n óo fi lélẹ̀ fún wọn, àwọn ọmọ tiwọn náà óo jókòó lórí ìtẹ́ rẹ títí lae.”

13 Nítorí OLUWA ti yan Sioni; ó fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀:

14 Ó ní, “Ìhín ni ibi ìsinmi mi títí lae, níhìn-ín ni n óo máa gbé, nítorí pé ó wù mí.

15 N óo bù sí oúnjẹ rẹ̀ lọpọlọpọ; n óo fi oúnjẹ tẹ́ àwọn aláìní ibẹ̀ lọ́rùn.

16 N óo gbé ẹ̀wù ìgbàlà wọ àwọn alufaa rẹ̀, àwọn eniyan mímọ́ rẹ̀ yóo sì kọrin ayọ̀.

17 Níbẹ̀ ni n óo ti fún Dafidi ní agbára; mo ti gbé àtùpà kalẹ̀ fún ẹni tí mo fi òróró yàn.

18 N óo da ìtìjú bo àwọn ọ̀tá rẹ̀ bí aṣọ, ṣugbọn adé orí rẹ̀ yóo máa tàn yinrinyinrin.”

133

1 Ó dára, ó sì dùn pupọ, bí àwọn ará bá ń gbé pọ̀ ní ìrẹ́pọ̀.

2 Ó dàbí òróró iyebíye tí a dà síni lórí, tí ó ṣàn dé irùngbọ̀n; bí ó ti ṣàn dé irùngbọ̀n Aaroni, àní, títí dé ọrùn ẹ̀wù rẹ̀.

3 Ó dàbí ìrì òkè Herimoni, tí ó sẹ̀ sórí òkè Sioni. Níbẹ̀ ni OLUWA ti ṣe ìlérí ibukun, àní, ìyè ainipẹkun.

134

1 Ẹ wá, ẹ yin OLUWA, gbogbo ẹ̀yin iranṣẹ rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ń sìn ín ninu ilé rẹ̀ lóru.

2 Ẹ gbé ọwọ́ yín sókè, kí ẹ gbadura ninu ilé mímọ́ rẹ̀, kí ẹ sì yin OLUWA.

3 Kí OLUWA tí ó dá ọ̀run ati ayé bukun yín láti Sioni wá.

135

1 Ẹ yin OLUWA. Ẹ yin orúkọ OLUWA; ẹ yìn ín, ẹ̀yin iranṣẹ rẹ̀,

2 ẹ̀yin tí ẹ̀ ń jọ́sìn ninu ilé OLUWA, tí ẹ wà ní àgbàlá ilé Ọlọrun wa.

3 Ẹ yin OLUWA, nítorí pé ó ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí i, nítorí pé olóore ọ̀fẹ́ ni.

4 Nítorí pé OLUWA ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀, ó ti yan Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.

5 Èmi mọ̀ pé OLUWA tóbi, ati pé ó ju gbogbo oriṣa lọ.

6 Bí ó ti wu OLUWA ni ó ń ṣe lọ́run ati láyé, ninu òkun ati ninu ibú.

7 Òun ló gbá ìkùukùu jọ láti òpin ilẹ̀ ayé, ó fi mànàmáná fún òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti inú ilé ìṣúra rẹ̀.

8 Òun ló pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti, ati teniyan ati tẹran ọ̀sìn.

9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ abàmì ati iṣẹ́ ìyanu sí ilẹ̀ Ijipti, ó rán sí Farao ati gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ̀.

10 Ẹni tí ó pa orílẹ̀-èdè pupọ run; ó pa àwọn ọba alágbára:

11 Sihoni ọba àwọn Amori, Ogu ọba Baṣani, ati gbogbo ọba ilẹ̀ Kenaani.

12 Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀; ó pín in fún Israẹli bí ohun ìní wọn.

13 OLUWA, orúkọ rẹ yóo wà títí lae, òkìkí rẹ óo sì máa kàn títí ayé.

14 OLUWA yóo dá àwọn eniyan rẹ̀ láre, yóo sì ṣàánú àwọn iranṣẹ rẹ̀.

15 Wúrà ati fadaka ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù fi ṣe oriṣa wọn, iṣẹ́ ọwọ́ eniyan ni wọ́n.

16 Wọ́n lẹ́nu, ṣugbọn wọn kò lè sọ̀rọ̀, wọ́n lójú, ṣugbọn wọn kò lè ríran.

17 Wọ́n létí, ṣugbọn wọn kò lè gbọ́ràn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí èémí kan ní ẹnu wọn.

18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n yóo dàbí wọn, ati gbogbo àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé wọn.

19 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, ẹ yin OLUWA!

20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ yìn ín!

21 Ẹ yin OLUWA ní Sioni, ẹni tí ń gbé Jerusalẹmu! Ẹ yin OLUWA!

136

1 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọrun tí ó ju gbogbo àwọn oriṣa lọ, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

3 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA tí ó ju gbogbo àwọn oluwa lọ, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

4 Òun nìkan ṣoṣo ní ń ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

5 Ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

6 ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lé orí omi, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

7 ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

8 Ó dá oòrùn láti máa ṣe àkóso ọ̀sán, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

9 Ó dá òṣùpá ati ìràwọ̀ láti máa ṣe àkóso òru, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

10 Ẹni tí ó pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

11 ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láàrin wọn, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

12 Pẹlu ipá ati ọwọ́ líle ni ó fi kó wọn jáde, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

13 Ẹni tí ó pín Òkun Pupa sí meji, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

14 ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli kọjá láàrin rẹ̀, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

15 ṣugbọn ó bi Farao ati àwọn ọmọ ogun rẹ̀ ṣubú ninu Òkun Pupa, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

16 Ẹni tí ó mú àwọn eniyan rẹ̀ la aṣálẹ̀ já, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

17 ẹni tí ó pa àwọn ọba ńlá, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

18 ó sì pa àwọn ọba olókìkí, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

19 Sihoni ọba àwọn Amori, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

20 ati Ogu ọba Baṣani, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

21 Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

22 ó fún àwọn ọmọ Israẹli, iranṣẹ rẹ̀, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

23 Òun ni ó ranti wa ní ipò ìrẹ̀lẹ̀ wa, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

24 ó sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

25 Ẹni tí ó pèsè oúnjẹ fún gbogbo ẹ̀dá alààyè, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

26 Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọrun ọ̀run, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

137

1 Lẹ́bàá odò Babiloni ni a jókòó, tí a sọkún, nígbà tí a ranti Sioni.

2 Lára igi wilo níbẹ̀ ni a fi hapu wa kọ́ sí,

3 nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn ti ní kí á kọrin fún àwọn. Àwọn tí ó ń pọ́n wa lójú sọ pé kí á dá àwọn lárayá, wọ́n ní, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa.”

4 Báwo ni a óo ṣe kọ orin OLUWA ní ilẹ̀ àjèjì?

5 Jerusalẹmu, bí mo bá gbàgbé rẹ, kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó rọ.

6 Kí ahọ́n mi lẹ̀ mọ́ èrìgì mi, bí n kò bá ranti rẹ, bí n kò bá sì fi Jerusalẹmu ṣe olórí ayọ̀ mi.

7 OLUWA, ranti ohun tí àwọn ará Edomu ṣe nígbà tí Jerusalẹmu bọ́ sọ́wọ́ ọ̀tá, tí wọn ń pariwo pé, “Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o títí dé ìpìlẹ̀ rẹ̀.”

8 Babiloni! Ìwọ apanirun! Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ̀san lára rẹ, fún gbogbo ohun tí o ti ṣe sí wa!

9 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá kó àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ, tí ó ṣán wọn mọ́ àpáta.

138

1 N óo máa yìn ọ́ tọkàntọkàn OLUWA, lójú àwọn oriṣa ni n óo máa kọrin ìyìn sí ọ.

2 Ní ìtẹríba, n óo kọjú sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ, n óo sì máa yin orúkọ rẹ, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ rẹ, nítorí pé o gbé ọ̀rọ̀ rẹ ati orúkọ rẹ ga ju ohunkohun lọ.

3 Ní ọjọ́ tí mo ké pè ọ́, o dá mi lóhùn, o sì fún mi ní agbára kún agbára.

4 OLUWA, gbogbo ọba ayé ni yóo máa yìn ọ́, nítorí pé wọ́n ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.

5 Wọn óo sì máa kọrin nípa iṣẹ́ OLUWA, nítorí pé ògo OLUWA tóbi.

6 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé OLUWA ga lọ́lá, ó ka àwọn onírẹ̀lẹ̀ sí, ṣugbọn ó mọ àwọn onigbeeraga lókèèrè.

7 Bí mo tilẹ̀ wà ninu ìpọ́njú, sibẹ, o dá mi sí; o dojú ìjà kọ ibinu àwọn ọ̀tá mi, o sì fi ọwọ́ agbára rẹ gbà mí.

8 OLUWA yóo mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ lórí mi, OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà títí lae. Má kọ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ sílẹ̀.

139

1 OLUWA, o ti yẹ̀ mí wò, o sì mọ̀ mí.

2 O mọ ìgbà tí mo jókòó, ati ìgbà tí mo dìde; o mọ èrò ọkàn mi láti òkèèrè réré.

3 O yẹ ìrìn ẹsẹ̀ mi ati àbọ̀sinmi mi wò; gbogbo ọ̀nà mi ni o sì mọ̀.

4 Kódà kí n tó sọ ọ̀rọ̀ jáde lẹ́nu, OLUWA, o ti mọ gbogbo nǹkan tí mo fẹ́ sọ patapata.

5 O pa mí mọ́, níwájú ati lẹ́yìn; o gbé ọwọ́ ààbò rẹ lé mi.

6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ́ ohun ìyanu fún mi, ó ga jù, ojú mi kò tó o.

7 Níbo ni mo lè sá lọ, tí ẹ̀mí rẹ kò ní sí níbẹ̀? Níbo ni mo lè sá gbà tí ojú rẹ kò ní tó mi?

8 Ǹ báà gòkè re ọ̀run, o wà níbẹ̀! Bí mo sì tẹ́ ibùsùn mi sí isà òkú, n óo bá ọ níbẹ̀.

9 Ǹ báà hu ìyẹ́, kí n fò lọ sí ibi ojúmọ́ ti ń mọ́ wá, kí n lọ pàgọ́ sí ibi tí òkun pin sí,

10 níbẹ̀ gan-an, ọwọ́ rẹ ni yóo máa tọ́ mi, tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóo sì dì mí mú.

11 Bí mo bá wí pé kí kìkì òkùnkùn bò mí mọ́lẹ̀, kí ọ̀sán di òru fún mi,

12 òkùnkùn gan-an kò ṣú jù fún ọ; òru mọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; lójú rẹ, ìmọ́lẹ̀ kò yàtọ̀ sí òkùnkùn.

13 Nítorí ìwọ ni o dá inú mi, ìwọ ni o sọ mí di odidi ní inú ìyá mi.

14 Mo yìn ọ́, nítorí pé ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ati ẹni ìyanu ni ọ́; ìyanu ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ! O mọ̀ mí dájú.

15 Nígbà tí à ń ṣẹ̀dá egungun mi lọ́wọ́ ní ìkọ̀kọ̀, tí ẹlẹ́dàá ṣẹ̀ṣẹ̀ ń ṣọnà sí mi lára ní àṣírí, kò sí èyí tí ó pamọ́ fún ọ.

16 Kí á tó dá mi tán ni o ti rí mi, o ti kọ iye ọjọ́ tí a pín fún mi sinu ìwé rẹ, kí ọjọ́ ayé mi tilẹ̀ tó bẹ̀rẹ̀ rárá.

17 Ọlọrun, iyebíye ni èrò rẹ lójú mi! Wọ́n pọ̀ pupọ ní iye.

18 Bí mo bá ní kí n kà wọ́n, wọ́n pọ̀ ju iyanrìn lọ; nígbà tí mo bá sì jí, ọ̀dọ̀ rẹ náà ni n óo wà.

19 Ọlọrun, ò bá jẹ́ pa àwọn eniyan burúkú, kí àwọn apànìyàn sì kúrò lọ́dọ̀ mi.

20 Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ọ̀tẹ̀ nípa rẹ, àwọn ọ̀tá rẹ ń ba orúkọ rẹ jẹ́.

21 OLUWA, mo kórìíra àwọn tí ó kórìíra rẹ; mo sì kẹ́gàn àwọn tí ń dìtẹ̀ sí ọ?

22 Mo kórìíra wọn dé òpin; ọ̀tá ni mo kà wọ́n kún.

23 Wádìí mi, Ọlọrun, kí o mọ ọkàn mi; yẹ̀ mí wò, kí o sì mọ èrò ọkàn mi.

24 Wò ó bí ọ̀nà ibi kan bá wà tí mò ń tọ̀, kí o sì tọ́ mi sí ọ̀nà ayérayé.

140

1 OLUWA, gbà mí lọ́wọ́ àwọn ẹni ibi; dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn oníwà ipá;

2 àwọn tí ó ń pète ibi lọ́kàn wọn, tí wọ́n sì ń dá ogun sílẹ̀ nígbàkúùgbà,

3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn, ó mú bí ahọ́n ejò; oró paramọ́lẹ̀ sì ń bẹ ninu eyín wọn.

4 OLUWA, ṣọ́ mi lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú; dáàbò bò mí lọ́wọ́ àwọn oníwà ipá, tí ó ń gbìmọ̀ láti ré mi lẹ́pa.

5 Àwọn agbéraga ti dẹ tàkúté sílẹ̀ dè mí, wọ́n dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún mi; wọ́n sì dẹ okùn sílẹ̀ fún mi lẹ́bàá ọ̀nà.

6 Mo wí fún OLUWA pé, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.” OLUWA, tẹ́tí sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7 OLUWA, OLUWA mi, alágbára tíí gbani là, ìwọ ni o dáàbò bò mí ní ọjọ́ ogun.

8 OLUWA, má jẹ́ kí ọwọ́ àwọn eniyan burúkú tẹ ohun tí wọn ń wá; má jẹ́ kí èrò ọkàn wọn ṣẹ.

9 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ibi ẹnu àwọn tí ó yí mi ká dà lé wọn lórí.

10 Jẹ́ kí ẹ̀yinná dà lé wọn lórí; jẹ́ kí wọn já sí kòtò, kí wọn má lè yọ.

11 Má jẹ́ kí abanijẹ́ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ lórí ilẹ̀ náà; jẹ́ kí oníwà ipá ko àgbákò kíákíá.

12 Mo mọ̀ pé OLUWA yóo gba ọ̀ràn olùpọ́njú rò, yóo sì ṣe ìdájọ́ òdodo fún àwọn aláìní.

13 Dájúdájú, àwọn olódodo yóo máa fi ọpẹ́ fún ọ; àwọn olóòótọ́ yóo sì máa gbé níwájú rẹ.

141

1 OLUWA, mo ké pè ọ́, tètè wá dá mi lóhùn, tẹ́tí sí ohùn mi nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.

2 Jẹ́ kí adura mi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ bíi turari, sì jẹ́ kí ọwọ́ adura tí mo gbé sókè dàbí ẹbọ àṣáálẹ́.

3 OLUWA, fi ìjánu sí mi ní ẹnu, sì ṣe aṣọ́nà ètè mi.

4 Má jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ibi, má sì jẹ́ kí n lọ́wọ́ sí iṣẹ́ ìkà. Má jẹ́ kí n bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ rìn pọ̀, má sì jẹ́ kí n jẹ ninu oúnjẹ àdídùn wọn.

5 N ò kọ̀ kí ẹni rere bá mi wí, n ò kọ̀ kí ó nà mí; kí ó ṣá ti fi ìfẹ́ bá mi wí. Ṣugbọn má jẹ́ kí eniyan burúkú tilẹ̀ ta òróró sí mi lórí, nítorí pé nígbàkúùgbà ni mò ń fi adura tako ìwà ibi wọn.

6 Nígbà tí ọwọ́ àwọn tí yóo dá wọn lẹ́bi bá tẹ̀ wọ́n, wọn óo gbà pé, òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ OLUWA.

7 Bí òkúta tí eniyan là, tí ó fọ́ yángá-yángá sílẹ̀, ni a óo fọ́n egungun wọn ká sí ẹnu ibojì.

8 Ṣugbọn ìwọ ni mo gbójúlé, OLUWA, Ọlọrun. Ìwọ ni asà mi, má fi mí sílẹ̀ láìní ààbò.

9 Pa mí mọ́ ninu ewu tàkúté, ati ti okùn tí àwọn aṣebi dẹ sílẹ̀ dè mí.

10 Jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú ṣubú sinu àwọ̀n ara wọn, kí èmi sì lọ láìfarapa.

142

1 Mo ké pe OLUWA, mo gbé ohùn ẹ̀bẹ̀ sókè sí i.

2 Mo tú ẹ̀dùn ọkàn mi palẹ̀ níwájú rẹ̀, mo sọ ìṣòro mi fún un.

3 Nígbà tí ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì, ó mọ ọ̀nà tí mo lè gbà. Wọ́n ti dẹ tàkúté sílẹ̀ fún mi ní ọ̀nà tí mò ń rìn.

4 Mo wo ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún mi yíká, mo rí i pé kò sí ẹni tí ó náání mi; kò sí ààbò fún mi, ẹnikẹ́ni kò sì bìkítà fún mi.

5 Mo ké pè ọ́, OLUWA, mo ní, “Ìwọ ni ààbò mi, ìwọ ni ìpín mi lórí ilẹ̀ alààyè.”

6 Gbọ́ igbe mi; nítorí wọ́n ti rẹ̀ mí sílẹ̀ patapata. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.

7 Yọ mí kúrò ninu ìhámọ́, kí n lè yin orúkọ rẹ lógo. Àwọn olódodo yóo yí mi ká, nítorí ọpọlọpọ oore tí o óo ṣe fún mi.

143

1 OLUWA, gbọ́ adura mi; fetí sí ẹ̀bẹ̀ mi! Dá mi lóhùn ninu òtítọ́ ati òdodo rẹ.

2 Má dá èmi ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ lẹ́jọ́, nítorí pé kò sí ẹ̀dá alààyè tí ẹjọ́ rẹ̀ lè tọ́ níwájú rẹ.

3 Ọ̀tá ti lé mi bá, ó ti lù mí bolẹ̀; ó jù mí sinu òkùnkùn, bí ẹni tí ó ti kú tipẹ́tipẹ́.

4 Nítorí náà ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì; ọkàn mi sì pòrúúruù.

5 Mo ranti ìgbà àtijọ́, mo ṣe àṣàrò lórí gbogbo ohun tí o ti ṣe, mo sì ronú lórí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

6 Mo na ọwọ́ sí ọ fún ìrànlọ́wọ́; bí òùngbẹ omi í tií gbẹ ilẹ̀ gbígbẹ, bẹ́ẹ̀ ni òùngbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi.

7 OLUWA, yára dá mi lóhùn! Ẹ̀mí mi ti fẹ́rẹ̀ pin! Má fara pamọ́ fún mi, kí n má baà dàbí àwọn tí ó ti lọ sinu isà òkú.

8 Jẹ́ kí n máa ranti ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ láràárọ̀, nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé. Kọ́ mi ní ọ̀nà tí n óo máa rìn, nítorí pé ìwọ ni mo gbójú sókè sí.

9 OLUWA, gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi; ìwọ ni mo sá di.

10 Kọ́ mi láti máa ṣe ìfẹ́ rẹ, nítorí pé ìwọ ni Ọlọrun mi. Jẹ́ kí ẹ̀mí rere rẹ máa tọ́ mi ní ọ̀nà tí ó tọ́.

11 Nítorí ti orúkọ rẹ, OLUWA, dá mi sí; ninu òtítọ́ rẹ, yọ mí ninu ìpọ́njú.

12 Ninu ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, pa àwọn ọ̀tá mi, kí o sì pa gbogbo àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi run, nítorí pé iranṣẹ rẹ ni mí.

144

1 Ìyìn ni fún OLUWA, àpáta mi, ẹni tí ó kọ́ mi ní ìjà jíjà, tí ó kọ́ mi ní iṣẹ́ ogun.

2 Òun ni àpáta mi, ààbò mi, odi mi, olùdáǹdè mi, asà mi, ẹni tí mo sá di. Òun ni ó tẹrí àwọn eniyan ba lábẹ́ rẹ̀.

3 OLUWA, kí ni eniyan jẹ́, tí o fi ń náání rẹ̀? Kí sì ni ọmọ eniyan tí o fi ń ranti rẹ̀?

4 Eniyan dàbí èémí, ọjọ́ ayé rẹ̀ sì dàbí òjìji tí ń kọjá lọ.

5 OLUWA, fa ojú ọ̀run wá sílẹ̀, kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá, fọwọ́ kan àwọn òkè ńlá, kí wọ́n máa rú èéfín.

6 Jẹ́ kí mànàmáná kọ, kí o sì tú wọn ká, ta ọfà rẹ, kí o tú wọn ká.

7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti òkè, kí o yọ mí ninu ibú omi; kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn àjèjì,

8 tí ẹnu wọn kún fún irọ́, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún èké.

9 Ọlọrun, n óo kọ orin titun sí ọ, n óo fi hapu olókùn mẹ́wàá kọrin sí ọ.

10 Ìwọ ni ò ń fún àwọn ọba ní ìṣẹ́gun, tí o sì gba Dafidi, iranṣẹ rẹ, là.

11 Gbà mí lọ́wọ́ idà ìkà, gbà mí lọ́wọ́ àwọn àjèjì, tí ẹnu wọ́n kún fún irọ́, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún èké.

12 Ní ìgbà èwe àwọn ọdọmọkunrin wa, jẹ́ kí wọ́n dàbí igi tí a gbìn tí ó dàgbà, kí àwọn ọdọmọbinrin wa dàbí òpó igun ilé, tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí bíi ti ààfin ọba.

13 Kí àká wa kún fún oniruuru oúnjẹ, kí àwọn aguntan wa bí ẹgbẹẹgbẹrun, àní, ẹgbẹẹgbaarun ninu pápá oko wa.

14 Kí àwọn mààlúù wa lóyún, kí wọ́n má rọ́nú, kí wọ́n má bí òkúmọ; kí ó má sí ariwo àjálù ní ìgboro wa.

15 Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí ó ní irú ibukun yìí; ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn.

145

1 Èmi óo gbé ọ ga, Ọlọrun mi, Ọba mi, n óo máa yin orúkọ rẹ lae ati laelae.

2 Lojoojumọ ni n óo máa yìn ọ́, tí n óo máa yin orúkọ rẹ lae ati laelae.

3 OLUWA tóbi, ìyìn sì yẹ ẹ́ lọpọlọpọ; àwámárìídìí ni títóbi rẹ̀.

4 Láti ìran dé ìran ni a óo máa yin iṣẹ́ rẹ, tí a óo sì máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ agbára ńlá rẹ.

5 Èmi óo máa ṣe àṣàrò lórí ẹwà ògo ọlá ńlá rẹ, ati iṣẹ́ ìyanu rẹ.

6 Eniyan óo máa kéde iṣẹ́ agbára rẹ tí ó yani lẹ́nu, èmi óo sì máa polongo títóbi rẹ.

7 Wọn óo máa pòkìkí bí oore rẹ ti pọ̀ tó, wọn óo sì máa kọrin sókè nípa òdodo rẹ.

8 Aláàánú ni OLUWA, olóore sì ni; kì í yára bínú, ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀.

9 OLUWA ṣeun fún gbogbo eniyan, àánú rẹ̀ sì ń bẹ lórí gbogbo ohun tí ó dá.

10 OLUWA, gbogbo ohun tí o dá ni yóo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, àwọn eniyan mímọ́ rẹ yóo sì máa yìn ọ́.

11 Wọn óo máa ròyìn ògo ìjọba rẹ, wọn óo sì máa sọ nípa agbára rẹ,

12 láti mú àwọn eniyan mọ agbára rẹ, ati ẹwà ògo ìjọba rẹ.

13 Ìjọba ayérayé ni ìjọba rẹ, yóo sì máa wà láti ìran dé ìran. Olóòótọ́ ni OLUWA ninu gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, olóore ọ̀fẹ́ sì ni ninu gbogbo ìṣe rẹ̀.

14 OLUWA gbé gbogbo àwọn tí ń ṣubú lọ dìde, ó sì gbé gbogbo àwọn tí a tẹrí wọn ba nàró.

15 Ojú gbogbo eniyan ń wò ọ́, o sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àsìkò.

16 Ìwọ la ọwọ́ rẹ, o sì tẹ́ gbogbo ẹ̀dá alààyè lọ́rùn.

17 Olódodo ni OLUWA ninu gbogbo ọ̀nà rẹ̀, aláàánú sì ni ninu gbogbo ìṣe rẹ̀.

18 OLUWA súnmọ́ gbogbo àwọn tí ń pè é, àní, àwọn tí ń pè é tọkàntọkàn.

19 Ó ń tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ lọ́rùn; ó ń gbọ́ igbe wọn, ó sì ń gbà wọ́n.

20 OLUWA dá gbogbo àwọn tí ó fẹ́ ẹ sí, ṣugbọn yóo pa gbogbo àwọn eniyan burúkú run.

21 Ẹnu mi yóo máa sọ̀rọ̀ ìyìn OLUWA; kí gbogbo ẹ̀dá máa yin orúkọ rẹ̀ lae ati laelae.

146

1 Ẹ yin OLUWA! Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi.

2 N óo máa yin OLUWA níwọ̀n ìgbà tí mo wà láyé; n óo máa kọrin ìyìn sí Ọlọrun mi níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè.

3 Má gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìjòyè; eniyan ni wọ́n, kò sì sí ìgbàlà lọ́dọ̀ wọn.

4 Bí ẹ̀mí wọn bá ti bọ́, wọn á pada di erùpẹ̀, ní ọjọ́ náà sì ni èrò inú wọn óo di ègbé.

5 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó fi Ọlọrun Jakọbu ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ̀, tí ó gbójú lé OLUWA, Ọlọrun rẹ̀.

6 Ọlọrun tí ó dá ọ̀run ati ayé, òkun ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀; Ọlọrun tíí máa ń pa àdéhùn rẹ̀ mọ́ títí lae,

7 ẹni tíí máa ń dá ẹjọ́ òdodo fún àwọn tí a ni lára; tí ń fún àwọn tí ebi ń pa ní oúnjẹ, OLUWA tíí tú àwọn tí ó wà ninu ìdè sílẹ̀.

8 A máa la ojú àwọn afọ́jú, a máa gbé àwọn tí a tẹrí wọn ba dúró; ó fẹ́ràn àwọn olódodo.

9 OLUWA ni olùṣọ́ àwọn àlejò, òun ni alátìlẹ́yìn àwọn opó ati aláìníbaba, ṣugbọn a máa da ète àwọn eniyan burúkú rú.

10 OLUWA yóo jọba títí lae, Sioni, Ọlọrun rẹ yóo jọba láti ìran dé ìran. Ẹ yin OLUWA.

147

1 Ẹ yin OLUWA! Nítorí tí ó dára láti máa kọ orin ìyìn sí Ọlọrun wa; nítorí olóore ni, orin ìyìn sì yẹ ẹ́.

2 OLUWA ní ń kọ́ ìlú Jerusalẹmu; òun ni yóo kó àwọn ọmọ Israẹli tí a fọ́n ká jọ.

3 Ó ń tu àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́ ninu, ó sì ń dí ọgbẹ́ wọn.

4 Òun ló mọ iye àwọn ìràwọ̀, òun ló sì fún gbogbo wọn lórúkọ.

5 OLUWA wa tóbi, ó sì lágbára pupọ òye rẹ̀ kò ní ìwọ̀n.

6 OLUWA ní ń gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ró, òun ni ó sì ń sọ àwọn eniyan burúkú di ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

7 Ẹ kọ orin ọpẹ́ sí OLUWA, ẹ fi hapu kọ orin dídùn sí Ọlọrun wa.

8 Ẹni tí ó fi ìkùukùu bo ojú ọ̀run, ó pèsè òjò fún ilẹ̀, ó mú koríko hù lórí òkè.

9 Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ, tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké.

10 Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí, kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà.

11 Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

12 Gbé OLUWA ga, ìwọ Jerusalẹmu! Yin Ọlọrun rẹ, ìwọ Sioni!

13 Ó fún ẹnubodè rẹ ní agbára, ó sì bukun àwọn tí ń gbé inú rẹ.

14 Ó jẹ́ kí alaafia wà ní ààlà ilẹ̀ rẹ, ó sì fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ ọ lábọ̀ọ́yó.

15 Ó pàṣẹ lórí ilẹ̀ ayé, àṣẹ rẹ̀ sì múlẹ̀ kíá.

16 Ó da òjò dídì bo ilẹ̀ bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú.

17 Ó sọ yìnyín sílẹ̀ bí òkò, ta ni ó lè fara da òtútù rẹ̀?

18 Ó sọ̀rọ̀, wọ́n yọ́, ó fẹ́ afẹ́fẹ́, omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn.

19 Ó ṣí ọ̀rọ̀ rẹ̀ payá fún Jakọbu, ó sì fi òfin ati ìlànà rẹ̀ han Israẹli.

20 Kò ṣe bẹ́ẹ̀ fún orílẹ̀-èdè kankan rí, wọn kò sì mọ ìlànà rẹ̀. Ẹ yin OLUWA!

148

1 Ẹ yin OLUWA! Ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ yìn ín lókè ọ̀run.

2 Ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin angẹli rẹ̀; ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin ọmọ ogun rẹ̀.

3 Ẹ yìn ín, oòrùn ati òṣùpá; ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ tí ń tàn.

4 Ẹ yìn ín, ọ̀run tí ó ga jùlọ; yìn ín, omi tí ó wà lójú ọ̀run.

5 Ẹ jẹ́ kí wọ́n máa yin orúkọ OLUWA, nítorí nípa àṣẹ rẹ̀ ni a fi dá wọn.

6 Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ títí laelae; ó sì pààlà fún wọn tí wọn kò gbọdọ̀ ré kọjá.

7 Ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin ẹ̀dá ayé, ẹ̀yin erinmi ńláńlá inú òkun ati gbogbo ibú omi;

8 iná ati yìnyín, ati ìrì dídì, ati ẹ̀fúùfù líle tí ń mú àṣẹ rẹ̀ ṣẹ.

9 Ẹ yìn ín, ẹ̀yin òkè ńláńlá ati òkè kéékèèké, ẹ̀yin igi eléso ati igi kedari;

10 ẹ̀yin ẹranko ìgbẹ́ ati ẹran ọ̀sìn, ẹ̀yin ẹ̀dá tí ń fàyà fà ati ẹyẹ tí ń fò.

11 Ẹ yìn ín, ẹ̀yin ọba ayé ati gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹ̀yin ìjòyè ati gbogbo onídàájọ́ ayé;

12 ẹ̀yin ọdọmọkunrin ati ọlọ́mọge, ẹ̀yin ọmọde ati ẹ̀yin àgbààgbà.

13 Ẹ jẹ́ kí wọn yin orúkọ OLUWA, nítorí pé orúkọ rẹ̀ nìkan ni ó ga jù; ògo rẹ̀ sì ga ju ayé ati ọ̀run lọ.

14 Ó ti fún àwọn eniyan rẹ̀ ní agbára, ó sì fún àwọn eniyan rẹ̀ mímọ́ ní ìyìn; ó fún àwọn eniyan Israẹli, tí ó wà lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ẹ yin OLUWA!

149

1 Ẹ yin OLUWA! Ẹ kọ orin titun sí OLUWA, ẹ kọrin ìyìn sí i ninu àwùjọ àwọn olóòótọ́.

2 Kí Israẹli máa yọ̀ ninu Ẹlẹ́dàá rẹ̀, kí àwọn ọmọ Sioni máa fò fún ayọ̀ pé àwọn ní Ọba.

3 Kí wọn máa fi ijó yin orúkọ rẹ̀, kí wọn máa fi ìlù ati hapu kọ orin aládùn sí i.

4 Nítorí pé inú OLUWA dùn sí àwọn eniyan rẹ̀, a sì máa fi ìṣẹ́gun dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé.

5 Kí àwọn olódodo máa ṣògo ninu ọlá; kí wọ́n máa kọrin ayọ̀ lórí ibùsùn wọn.

6 Kí wọn máa fi ohùn wọn yin Ọlọrun; kí idà olójú meji sì wà ní ọwọ́ wọn,

7 láti gbẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ati láti jẹ àwọn eniyan wọn níyà;

8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba orílẹ̀-èdè mìíràn, ati láti fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ de àwọn ọlọ́lá wọn;

9 láti ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀. Ògo gbogbo àwọn olódodo nìyí. Ẹ yin OLUWA!

150

1 Ẹ yin OLUWA! Ẹ yin Ọlọrun ninu ibi mímọ́ rẹ̀; ẹ yìn ín ninu òfuurufú rẹ̀ tí ó lágbára.

2 Ẹ yìn ín fún iṣẹ́ ńlá rẹ̀; ẹ yìn ín nítorí pé ó tóbi pupọ.

3 Ẹ fi ariwo fèrè yìn ín; ẹ fi fèrè ati hapu yìn ín.

4 Ẹ fi ìlù ati ijó yìn ín; ẹ fi gòjé ati dùùrù yìn ín.

5 Ẹ fi aro olóhùn òkè yìn ín; ẹ fi aro olóhùn gooro yìn ín.

6 Kí gbogbo nǹkan ẹlẹ́mìí yin OLUWA! Ẹ yin OLUWA!