1 Ẹ wò ó bí ìlú tí ó kún fún eniyan tẹ́lẹ̀ ti di ahoro, tí ó wá dàbí opó! Ìlú tí ó tóbi láàrin àwọn orílẹ̀-èdè tẹ́lẹ̀! Tí ó sì dàbí ọmọ ọba obinrin láàrin àwọn ìlú yòókù. Ó ti wá di ẹni àmúsìn.
2 Ó ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn lóru, omijé ń dà lójú rẹ̀, kò sì sí ẹni tí yóo tù ú ninu, láàrin àwọn alajọṣepọ rẹ̀. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti dà á, wọ́n dìtẹ̀ mọ́ ọn, wọ́n sì di ọ̀tá rẹ̀.
3 Juda ti lọ sí ìgbèkùn, wọ́n sì ń fi tipátipá mú un sìn. Nisinsinyii, ó ń gbé ààrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, kò sì ní ibi ìsinmi. Ọwọ́ àwọn tí wọn ń lépa rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́, ninu ìdààmú rẹ̀.
4 Àwọn ọ̀nà tó lọ sí Sioni ń ṣe ìdárò, nítorí kò sí ẹni tí ó ń gba ibẹ̀ lọ síbi àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀ mọ́. Àwọn ẹnubodè rẹ̀ ti di ahoro, àwọn alufaa rẹ̀ sì ń kẹ́dùn. Wọ́n ń pọ́n àwọn ọmọbinrin rẹ̀ lójú, òun pàápàá sì ń joró lọpọlọpọ.
5 Àwọn ọ̀tá ilẹ̀ Juda ti borí rẹ̀, wọ́n ti wá di ọ̀gá rẹ̀, nítorí pé, OLUWA ń jẹ ẹ́ níyà fún ọpọlọpọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, àwọn ọ̀tá ti ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣáájú, wọ́n ti kó wọn nígbèkùn lọ.
6 Gbogbo ògo Jerusalẹmu ti fò lọ kúrò lára rẹ̀, àwọn olórí rẹ̀ dàbí àgbọ̀nrín tí kò rí koríko tútù jẹ; agbára kò sí fún wọn mọ́, wọ́n ń sálọ níwájú àwọn tí ń lé wọn.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú ati ìbànújẹ́, Jerusalẹmu ranti àwọn nǹkan iyebíye tí ó ní ní ìgbà àtijọ́. Nígbà tí àwọn eniyan rẹ̀ bọ́ sọ́wọ́ ọ̀tá, tí kò sì sí ẹni tí yóo ràn wọ́n lọ́wọ́. Àwọn ọ̀tá bẹ̀rẹ̀ sí yọ̀ ọ́, wọ́n sì ń fi ṣẹ̀sín nítorí ìṣubú rẹ̀.
8 Jerusalẹmu ti dẹ́ṣẹ̀ burúkú, nítorí náà ó ti di eléèérí. Àwọn tí wọn ń bu ọlá fún un tẹ́lẹ̀ ti ń kẹ́gàn rẹ̀, nítorí pé wọ́n ti rí ìhòòhò rẹ̀. Òun pàápàá ń kérora, ó sì fi ojú pamọ́.
9 Ìwà èérí rẹ̀ hàn níbi ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, kò sì bìkítà fún ìparun tí ń bọ̀. Nítorí náà ni ìṣubú rẹ̀ fi pọ̀, tí kò sì fi ní olùtùnú. Ó ké pe OLUWA pé kí ó ṣíjú wo ìnira òun, nítorí pé ọ̀tá ti borí rẹ̀.
10 Ọ̀tá ti tọwọ́ bọ ilé ìṣúra rẹ̀, wọ́n sì ti kó gbogbo nǹkan iyebíye inú rẹ̀ lọ; ó ń wo àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, tí wọn ń wọ ibi mímọ́ rẹ̀. Àwọn tí ó pàṣẹ pé wọn kò gbọdọ̀ dé àwùjọ àwọn eniyan rẹ̀.
11 Gbogbo àwọn eniyan rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n ń fi ìṣúra wọn ṣe pàṣípààrọ̀ fún oúnjẹ kí wọ́n baà lè lágbára. Jerusalẹmu ń sunkún pé, “Bojúwò mí, OLUWA, nítorí pé mo di ẹni ẹ̀gàn.”
12 Ó ní, “Ṣé ọ̀rọ̀ yìí kò kàn yín ni, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń kọjá lọ? Ẹ̀yin náà ẹ wò ó, kí ẹ ṣe akiyesi rẹ̀, bóyá ìbànújẹ́ kan wà tí ó dàbí èyí tí ó dé bá mi yìí; tí OLUWA mú kí ó dé bá mi, ní ọjọ́ ibinu gbígbóná rẹ̀.
13 “Ó rán iná láti òkè ọ̀run wá; ó dá a sí egungun mi; ó dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún mi; ó sì dá mi pada. Mo dàbí odi, mo sì fi ìgbà gbogbo dákú.
14 “Ó di ẹ̀ṣẹ̀ mi bí àjàgà, ó gbé e kọ́ mi lọ́rùn, ó sì sọ mí di aláìlágbára. OLUWA ti fi mí lé àwọn tí n kò lè dojú kọ lọ́wọ́.
15 “OLUWA ti fi ẹsẹ̀ tẹ àwọn akọni mi mọ́lẹ̀; ó pe ọpọlọpọ eniyan jọ sí mi, ó ní kí wọ́n pa àwọn ọdọmọkunrin mi; OLUWA ti tẹ àwọn ọmọ Juda ní àtẹ̀rẹ́, bí ẹni tẹ èso àjàrà fún ọtí waini.
16 “Nítorí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọnyi ni mo ṣe sọkún; tí omijé ń dà lójú mi; olùtùnú jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí ó lè dá mi lọ́kàn le. Àwọn ọmọ mi ti di aláìní, nítorí pé àwọn ọ̀tá ti borí wa.
17 “Sioni na ọwọ́ rẹ̀ fún ìrànwọ́, Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́, OLUWA ti pàṣẹ pé, kí àwọn aládùúgbò Jakọbu di ọ̀tá rẹ̀; Jerusalẹmu sì ti di eléèérí láàrin wọn.
18 “Ohun tí ó tọ́ ni OLUWA ṣe, nítorí mo ti ṣe àìgbọràn sí ọ̀rọ̀ rẹ̀; ṣugbọn, ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan, ẹ kíyèsí ìjìyà mi; wọ́n ti kó àwọn ọdọmọbinrin ati ọdọmọkunrin mi lọ sí ìgbèkùn.
19 “Mo ké pe àwọn alajọṣepọ mi, ṣugbọn títàn ni wọ́n tàn mí; àwọn alufaa ati àwọn àgbààgbà mi ṣègbé láàrin ìlú, níbi tí wọn ti ń wá oúnjẹ kiri, tí wọn óo jẹ, kí wọn lè lágbára
20 “Bojúwò mí, OLUWA, nítorí mo wà ninu ìpọ́njú, ọkàn mi ti dàrú, inú mi bàjẹ́, nítorí pé mo ti hùwà ọ̀tẹ̀ lọpọlọpọ. Níta gbangba, ogun ń pa mí lọ́mọ; bákan náà ni ikú ń bẹ ninu ilé.
21 “Gbọ́ bí mo ti ń kérora, kò sí ẹnìkan tí yóo tù mí ninu. Gbogbo àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ nípa ìyọnu mi; inú wọn sì dùn, pé ìwọ ni o kó ìyọnu bá mi. Jẹ́ kí ọjọ́ tí o dá tètè pé, kí àwọn náà lè dàbí mo ti dà.
22 “Ranti gbogbo ìwà ibi wọn, kí o sì jẹ wọ́n níyà; bí o ti jẹ mí níyà, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
1 Ẹ wò bí OLUWA ti fi ibinu fi ìkùukùu bo Sioni mọ́lẹ̀. Ó ti wọ́ ògo Israẹli lu láti òkè ọ̀run sórí ilẹ̀ ayé; kò tilẹ̀ ranti àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ibinu rẹ̀.
2 OLUWA ti pa gbogbo ibùgbé Jakọbu run láìsí àánú. Ó ti fi ibinu wó ibi ààbò Juda lulẹ̀. Ó ti rẹ ìjọba ati àwọn aláṣẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó fi àbùkù kàn wọ́n.
3 Ó ti fi ibinu gbígbóná rẹ̀, pa àwọn alágbára Israẹli; ó kọ̀, kò ràn wọ́n lọ́wọ́, nígbà tí àwọn ọ̀tá dojú kọ wọ́n. Ó jó àwọn ọmọ Jakọbu bí iná, ó sì pa gbogbo ohun tí wọn ní run.
4 Ó kẹ́ ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá, ó múra bí aninilára. Gbogbo ògo wa ló parun lójú wa, ó sì tú ibinu rẹ̀ jáde bí iná, ninu àgọ́ Sioni.
5 OLUWA ṣe bí ọ̀tá, ó ti pa Israẹli run. Ó ti pa gbogbo ààfin rẹ̀ run, ó sọ àwọn ibi ààbò rẹ̀ di àlàpà ó sì sọ ọ̀fọ̀ ati ẹkún Juda di pupọ.
6 Ó wó àgọ́ rẹ̀ lulẹ̀, bí ìgbà tí eniyan wó ahéré oko. Ó pa gbogbo ibi tí wọ́n ti ń ṣe àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀ run. OLUWA ti fi òpin sí àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀, ati ọjọ́ ìsinmi ní Sioni. Ó sì ti fi ibinu gbígbóná rẹ̀, kọ ọba ati alufaa sílẹ̀.
7 OLUWA kò bìkítà fún pẹpẹ rẹ̀ mọ́, ó sì ti kọ ibi mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Ó ti fi odi ààfin rẹ̀ lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́; wọ́n pariwo ńlá ninu ilé OLUWA gẹ́gẹ́ bíi ti ọjọ́ àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀.
8 OLUWA ti pinnu láti wó odi Sioni lulẹ̀. Ó fi okùn ìwọ̀n wọ̀n ọ́n, kò sì rowọ́ láti parun. Ó jẹ́ kí ilé ìṣọ́ ati odi ìlú wó lulẹ̀ pẹlu ìbànújẹ́, wọ́n sì di àlàpà papọ̀.
9 Àwọn ẹnubodè rẹ̀ ti rì, wọ́n ti wọlẹ̀; ó ti ṣẹ́ àwọn ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn bodè; ọba rẹ̀ ati àwọn olórí rẹ̀ wà láàrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn; òfin kò sí mọ́, àwọn wolii rẹ̀ kò sì ríran láti ọ̀dọ̀ OLUWA mọ́.
10 Àwọn àgbààgbà Sioni jókòó lórí ilẹ̀, wọ́n dákẹ́ rọ́rọ́, wọ́n ku eruku sórí, wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀. Àwọn ọmọbinrin Jerusalẹmu doríkodò.
11 Ẹkún sísun ti sọ ojú mi di bàìbàì, ìdààmú bá ọkàn mi; ìbànújẹ́ sì mú kí ó rẹ̀wẹ̀sì nítorí ìparun àwọn eniyan mi, nítorí pé àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ ati àwọn ọmọ ọwọ́ ń dákú lójú pópó láàrin ìlú.
12 Bí wọ́n ti ń dákú láàrin ìlú, bí ẹni tí a ṣá lọ́gbẹ́, tí wọ́n sì ń kú lọ lẹ́yìn ìyá wọn, wọ́n ń sọkún sí àwọn ìyá wọn pé: “Ebi ń pa wá, òùngbẹ sì ń gbẹ wá.”
13 Kí ni mo lè sọ nípa rẹ, kí sì ni ǹ bá fi ọ́ wé, Jerusalẹmu? Kí ni mo lè fi wé ọ, kí n lè tù ọ́ ninu, ìwọ Sioni? Nítorí bí omi òkun ni ìparun rẹ gbòòrò; ta ló lè mú ọ pada bọ̀ sípò?
14 Ìran èké ati ti ẹ̀tàn ni àwọn wolii rẹ ń rí sí ọ; wọn kò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn ọ́, kí wọ́n lè dá ire rẹ pada, ṣugbọn wọ́n ń ríran èké ati ìran ẹ̀tàn sí ọ.
15 Gbogbo àwọn tí ń rékọjá lọ ń pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí, wọ́n ń pòṣé, wọ́n sì ń mi orí wọn sí ọ, Jerusalẹmu. Wọ́n ń sọ pé: “Ṣé ìlú yìí ni à ń pè ní ìlú tí ó lẹ́wà jùlọ, tí ó jẹ́ ayọ̀ gbogbo ayé?”
16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ọ́ ṣẹ̀sín, wọ́n ń pòṣé, wọ́n ń fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Wọ́n ń wí pé: “A ti pa á run! Ọjọ́ tí a tí ń retí nìyí; ọwọ́ wa ti tẹ Jerusalẹmu wàyí! A ti rí ohun tí à ń wá!”
17 OLUWA ti ṣe bí ó ti pinnu, ó ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ, bí ó ti sọ ní ìgbà àtijọ́. Ó ti wó ọ lulẹ̀ láìṣàánú rẹ; ó ti jẹ́ kí ọ̀tá yọ̀ ọ́, ó ti fún àwọn ọ̀tá rẹ ni agbára kún agbára.
18 Ẹ kígbe sí OLUWA, ẹ̀yin ará Sioni! Ẹ jẹ́ kí omi máa dà lójú yín pòròpòrò tọ̀sán-tòru; ẹ má sinmi, ẹ má sì jẹ́ kí oorun kùn yín.
19 Ẹ dìde, ẹ kígbe lálẹ́, ní àkókò tí àwọn aṣọ́de ń bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́! Ẹ tú ẹ̀dùn ọkàn yín jáde bí omi níwájú OLUWA! Ẹ gbé ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sókè sí i, nítorí ẹ̀mí àwọn ọmọ yín tí ebi ń pa kú lọ ní gbogbo ìkóríta.
20 Wò ó! OLUWA, ṣe akiyesi ohun tí ń ṣẹlẹ̀! Wo àwọn tí ò ń ṣe irú èyí sí! Ṣé ó yẹ kí àwọn obinrin máa jẹ ọmọ wọn? Ọmọ ọwọ́ tí wọn ń tọ́jú! Ṣé ó yẹ kí á pa alufaa ati wolii, ní ibi mímọ́ OLUWA?
21 Àtàwọn ọ̀dọ́, àtàwọn arúgbó wọ́n kú kalẹ̀ lọ lójú pópó, àtàwọn ọdọmọbinrin, àtàwọn ọdọmọkunrin mi, gbogbo wọn ni idà ti pa. Ní ọjọ́ ibinu rẹ ni o pa wọ́n, o pa wọ́n ní ìpakúpa láìṣàánú wọn.
22 O pe àwọn ọ̀tá mi jọ sí mi bí ẹni peniyan síbi àjọ̀dún; kò sì sí ẹni tí ó yè ní ọjọ́ ibinu rẹ, OLUWA. Ọ̀tá mi pa àwọn ọmọ mi run, àwọn tí mo tọ́, tí mo sì fẹ́ràn.
1 Èmi ni mo mọ bí eniyan tií rí ìpọ́njú, tí mo mọ bí Ọlọrun tií fi ibinu na eniyan ní pàṣán.
2 Ó lé mi wọ inú òkùnkùn biribiri.
3 Dájúdájú, ó ti dojú kọ mí, ó sì bá mi jà léraléra tọ̀sán-tòru.
4 Ó ti jẹ́ kí n rù kan egungun, ó sì ti fọ́ egungun mi.
5 Ó dótì mí, ó fi ìbànújẹ́ ati ìṣẹ́ yí mi káàkiri.
6 Ó fi mí sinu òkùnkùn bí òkú tí ó ti kú láti ọjọ́ pípẹ́.
7 Ó mọ odi yí mi ká, ó sì fi ẹ̀wọ̀n wúwo dè mí, kí n má baà lè sálọ.
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ké pè é fún ìrànlọ́wọ́, sibẹsibẹ kò gbọ́ adura mi.
9 Ó to òkúta gbígbẹ́ dí ọ̀nà mi, ó mú kí ọ̀nà mí wọ́.
10 Ó ba dè mí bí ẹranko ìjàkùmọ̀, ó lúgọ bíi kinniun,
11 Ó wọ́ mi kúrò lójú ọ̀nà mi, ó fà mí ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, ó sì ti sọ mí di alailẹnikan.
12 Ó kẹ́ ọfà, ó fa ọrun rẹ̀, ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Ó mú gbogbo ọfà tí ó wà ninu apó rẹ̀ ó ta wọ́n mọ́ mi lọ́kàn.
14 Mo wá di ẹni yẹ̀yẹ́ lọ́dọ̀ gbogbo eniyan, ẹni tí wọ́n fi ń kọrin tọ̀sán-tòru.
15 Ó mú kí ọkàn mi kún fún ìbànújẹ́, ó fún mi ní iwọ mu ní àmuyó.
16 Ó fẹnu mi gbolẹ̀, títí yangí fi ká mi léyín; ó gún mi mọ́lẹ̀ ninu eruku
17 Ọkàn mi kò ní alaafia, mo ti gbàgbé ohun tí ń jẹ́ ayọ̀.
18 Nítorí náà, mo wí pé, “Ògo mi ti tán, ati gbogbo ohun tí mò ń retí lọ́dọ̀ OLUWA.”
19 Ranti ìyà ati ìbànújẹ́ mi, ati ìrora ọkàn mi!
20 Mò ń ranti nígbà gbogbo, ọkàn mi sì ń rẹ̀wẹ̀sì.
21 Ṣugbọn mo tún ń ranti nǹkankan, mo sì ní ìrètí.
22 Nítorí pé Ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀ kò nípẹ̀kun, àánú rẹ̀ kò sì lópin;
23 ọ̀tun ni wọ́n láràárọ̀, òtítọ́ rẹ̀ pọ̀.
24 Ọkàn mi wí pé, “OLUWA ni ìpín mi, nítorí náà lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ìrètí mi wà.”
25 OLUWA a máa ṣe oore fún àwọn tí wọn dúró dè é, tí wọn sì ń wá ojurere rẹ̀.
26 Ó dára kí eniyan dúró jẹ́ẹ́, de ìgbàlà OLUWA.
27 Ó dára kí eniyan foríti àjàgà ìtọ́sọ́nà ní ìgbà èwe.
28 Kí ó fi ọwọ́ lẹ́rán, kí ó dákẹ́, kí ó sì máa wòye, nítorí Ọlọrun ni ó gbé àjàgà náà kọ́ ọ lọ́rùn.
29 Kí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀, bóyá ìrètí lè tún wà fún un.
30 Kí ó kọ etí rẹ̀ sí ẹni tí ó fẹ́ gbá a létí, kí wọ́n sì fi àbùkù kàn án.
31 Nítorí OLUWA kò ní ta wá nù títí lae.
32 Bí ó tilẹ̀ mú kí ìbànújẹ́ dé bá wa, yóo ṣàánú wa, yóo tù wá ninu, gẹ́gẹ́ bí ọpọlọpọ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
33 Nítorí pé kì í kàn déédé ni eniyan lára tabi kí ó mú ìbànújẹ́ dé bá eniyan láìní ìdí.
34 OLUWA kò faramọ́ pé kí á máa ni àwọn ẹlẹ́wọ̀n lára lórí ilẹ̀ ayé,
35 kí á máa já ẹ̀tọ́ olódodo gbà lọ́wọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá Ògo,
36 tabi kí á du eniyan ní ìdájọ́ òdodo.
37 Ta ló pàṣẹ nǹkankan rí tí ó sì rí bẹ́ẹ̀, láìjẹ́ pé OLUWA ló fi ọwọ́ sí i?
38 Àbí kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá Ògo ni rere ati burúkú ti ń jáde?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè kan yóo fi máa ráhùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Ẹ jẹ́ kí á yẹ ara wa wò, kí á tún ọ̀nà wa ṣe, kí á sì yipada sí ọ̀dọ̀ OLUWA.
41 Ẹ jẹ́ kí á gbé ojú wa sókè, kí á ra ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Ọlọrun ọ̀run:
42 “A ti ṣẹ̀, a sì ti ṣoríkunkun, ìwọ OLUWA kò sì tíì dáríjì wá.
43 “O gbé ibinu wọ̀ bí ẹ̀wù, ò ń lépa wa, o sì ń pa wá láì ṣàánú wa.
44 O ti fi ìkùukùu bo ara rẹ, tóbẹ́ẹ̀ tí adura kankan kò lè kọjá sọ́dọ̀ rẹ.
45 O ti sọ wá di ààtàn ati ohun ẹ̀gbin láàrin àwọn eniyan.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ń wẹnu sí wa lára.
47 Ẹ̀rù ati ìṣubú, ìsọdahoro ati ìparun ti dé bá wa.
48 Omijé ń dà pòròpòrò lójú mi, nítorí ìparun àwọn eniyan mi.
49 “Omijé yóo máa dà pòròpòrò lójú mi láì dáwọ́ dúró, ati láìsinmi.
50 Títí OLUWA yóo fi bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, tí yóo sì rí wa.
51 Ìbànújẹ́ bá mi, nígbà tí mo rí ibi tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọbinrin ìlú mi.
52 “Àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí ń dọdẹ mi bí ìgbà tí eniyan ń dọdẹ ẹyẹ.
53 Wọ́n jù mí sinu ihò láàyè, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí sọ òkúta lù mí mọ́lẹ̀.
54 Omi bò mí mọ́lẹ̀, mo ní, ‘Mo ti gbé.’
55 “Mo ké pe orúkọ rẹ, OLUWA, láti inú kòtò jíjìn.
56 O gbọ́ ẹ̀bẹ̀ tí mò ń bẹ̀ pé, ‘Má ṣe di etí rẹ sí igbe tí mò ń ké fún ìrànlọ́wọ́.’
57 O súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi nígbà tí mo pè ọ́, o dá mi lóhùn pé, ‘Má bẹ̀rù.’
58 “OLUWA, o ti gba ìjà mi jà, o ti ra ẹ̀mí mi pada.
59 O ti rí nǹkan burúkú tí wọ́n ṣe sí mi, OLUWA, dá mi láre.
60 O ti rí gbogbo ìgbẹ̀san wọn, ati gbogbo ète wọn lórí mi.
61 “O ti gbọ́ bí wọn tí ń pẹ̀gàn mi, OLUWA, ati gbogbo ète wọn lórí mi.
62 Gbogbo ọ̀rọ̀ ati èrò àwọn ọ̀tá mi sí mi: ibi ni lojoojumọ.
63 Kíyèsí i, wọn ìbáà jókòó, wọn ìbáà dìde dúró, èmi ni wọ́n máa fi ń kọrin.
64 “O óo san ẹ̀san fún wọn, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
65 Jẹ́ kí ojú inú wọn fọ́, kí ègún rẹ sì wà lórí wọn.
66 Fi ibinu lépa wọn, OLUWA, sì pa wọ́n run láyé yìí.”
1 Wo bí wúrà ti dọ̀tí, tí ojúlówó wúrà sì yipada; tí àwọn òkúta Tẹmpili mímọ́ sì fọ́nká ní gbogbo ìkóríta.
2 Ẹ wo àwọn ọdọmọkunrin Sioni, àwọn ọmọ tí wọn níye lórí bí ojúlówó wúrà, tí a wá ń ṣe bí ìkòkò amọ̀; àní, bí ìkòkò amọ̀ lásánlàsàn.
3 Àwọn ajáko a máa fún àwọn ọmọ wọn lọ́mú. Ṣugbọn àwọn eniyan mi ti di ìkà, bí ògòǹgò inú aṣálẹ̀.
4 Ahọ́n ọmọ ọmú lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu rẹ̀ nítorí òùngbẹ. Àwọn ọmọde ń tọrọ oúnjẹ, ṣugbọn kò sí ẹni tí ó fún wọn.
5 Àwọn tí wọn tí ń jẹ oúnjẹ àdídùn di ẹni tí ń ṣa ilẹ̀ jẹ kiri ní ìgboro. Àwọn tí wọn tí ń fi aṣọ àlàárì bora di ẹni tí ń sùn lórí òkítì eérú.
6 Ìjìyà àwọn eniyan mi pọ̀ ju ti àwọn ará Sodomu lọ, Sodomu tí ó parun lójijì, láìjẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn án.
7 Àwọn olórí wọn kò ní àléébù kankan, Ọwọ́ wọn mọ́, inú wọn funfun nini, wọ́n dára ju egbin lọ, ẹwà wọn sì dàbí ẹwà iyùn.
8 Ṣugbọn nisinsinyii, ojú wọn dúdú ju èédú lọ, kò sí ẹni tí ó dá wọn mọ̀ láàrin ìgboro, awọ ara wọn ti hunjọ lórí egungun wọn, wọ́n wá gbẹ bí igi.
9 Ti àwọn tí wọ́n kú ikú ogun sàn ju àwọn tí wọ́n kú ikú ebi lọ, àwọn tí ebi pa joró dójú ikú, nítorí àìsí oúnjẹ ninu oko.
10 Àwọn obinrin tí wọn ní ojú àánú ti fi ọwọ́ ara wọn se ọmọ wọn jẹ, wọ́n fi ọmọ wọn ṣe oúnjẹ jẹ, nígbà tí ìparun dé bá àwọn eniyan mi.
11 OLUWA bínú gidigidi, ó tú ibinu gbígbóná rẹ̀ jáde. OLUWA dá iná kan ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo aráyé kò gbà pé ó lè ṣẹlẹ̀, pé ọ̀tá lè wọ ẹnubodè Jerusalẹmu.
13 Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wolii rẹ̀ ló fa èyí, ati àìdára àwọn alufaa rẹ̀, tí wọ́n pa olódodo láàrin ìlú.
14 Wọ́n ń káàkiri bí afọ́jú láàrin ìgboro, ẹ̀jẹ̀ àwọn tí wọ́n pa sọ wọ́n di aláìmọ́ tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15 Àwọn eniyan ń kígbe lé wọn lórí pé; “Ẹ máa lọ! Ẹ̀yin aláìmọ́! Ẹ máa kóra yín lọ! Ẹ má fi ọwọ́ kan nǹkankan!” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe di ìsáǹsá ati alárìnkiri, nítorí àwọn eniyan ń wí láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè pé, “Àwọn wọnyi kò gbọdọ̀ bá wa gbé pọ̀ mọ́.”
16 OLUWA fúnrarẹ̀ ti tú wọn ká, kò sì ní náání wọn mọ́. Kò ní bọlá fún àwọn alufaa wọn, kò sì ní fi ojurere wo àwọn àgbààgbà.
17 A wọ̀nà títí ojú wa di bàìbàì, asán ni ìrànlọ́wọ́ tí à ń retí jásí. A wọ̀nà títí fún ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò lè gbani là.
18 Àwọn eniyan ń ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ wa, tóbẹ́ẹ̀ tí a kò lè rìn gaara ní ìgboro. Ìparun wa súnmọ́lé, ọjọ́ ayé wa ti níye, nítorí ìparun wa ti dé.
19 Àwọn tí wọn ń lépa wa yára ju idì tí ń fò lójú ọ̀run lọ. Wọ́n ń lé wa lórí òkè, wọ́n sì ba dè wá ninu aṣálẹ̀.
20 Ẹ̀mí àwa ẹni àmì òróró OLUWA bọ́ sinu kòtò wọn, OLUWA tí à ń sọ nípa rẹ̀ pé, lábẹ́ òjìji rẹ̀ ni a óo máa gbé láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.
21 Ẹ máa yọ̀, kí inú yín sì máa dùn, ẹ̀yin ará Edomu, tí ń gbé ilẹ̀ Usi. Ṣugbọn ife náà yóo kọjá lọ́dọ̀ yín, ẹ óo mu ún ní àmuyó, ẹ óo sì tú ara yín síhòòhò.
22 Ẹ ti jìyà ẹ̀ṣẹ̀ yín ní àjẹpé, ẹ̀yin ará Sioni, OLUWA kò ní fi yín sílẹ̀ ní ìgbèkùn mọ́. Ṣugbọn yóo jẹ ẹ̀yin ará Edomu níyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, yóo tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ yín.
1 OLUWA, ranti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa, Ṣe akiyesi ẹ̀sín wa.
2 Àwọn ilẹ̀ àjogúnbá ẹni ẹlẹ́ni, ilé wa sì ti di ti àwọn àjèjì.
3 A ti di aláìníbaba, ọmọ òrukàn àwọn ìyá wa kò yàtọ̀ sí opó.
4 Owó ni a fi ń ra omi tí à ń mu, rírà ni a sì ń ra igi tí a fi ń dáná.
5 Àwọn tí wọn ń lépa wa ti bá wa, ó ti rẹ̀ wá, a kò sì ní ìsinmi.
6 A ti fa ara wa kalẹ̀ fún àwọn ará Ijipti ati àwọn ará Asiria nítorí oúnjẹ tí a óo jẹ.
7 Àwọn baba wa ni wọ́n dẹ́ṣẹ̀, àwọn sì ti kú, ṣugbọn àwa ni à ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Àwọn ẹrú ní ń jọba lé wa lórí, kò sì sí ẹni tí yóo gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Ẹ̀mí wa ni à ń fi wéwu, kí á tó rí oúnjẹ, nítorí ogun tí ó wà ninu aṣálẹ̀.
10 Awọ ara wa gbóná bí iná ààrò, nítorí ìyàn tí ó mú lọpọlọpọ.
11 Tipátipá ni wọ́n fi ń bá àwọn obinrin lòpọ̀ ní Sioni, ati àwọn ọmọbinrin tí wọn kò tíì mọ ọkunrin ní Juda.
12 Wọ́n fi okùn so ọwọ́ àwọn olórí rọ̀, wọn kò sì bọ̀wọ̀ fún àwọn àgbààgbà.
13 Wọ́n fi ipá mú àwọn ọdọmọkunrin pé kí wọn máa lọ ọlọ, àwọn ọmọde ru igi títí àárẹ̀ mú wọn!
14 Àwọn àgbààgbà ti sá kúrò ní ẹnubodè; àwọn ọdọmọkunrin sì ti dákẹ́ orin kíkọ.
15 Inú wa kò dùn mọ́; ijó wa ti yipada, ó ti di ọ̀fọ̀.
16 Adé ti ṣíbọ́ lórí wa! A gbé! Nítorí pé a ti dẹ́ṣẹ̀,
17 nítorí náà, ọkàn wa ti rẹ̀wẹ̀sì; ojú wa sì ti di bàìbàì.
18 Nítorí òkè Sioni tí ó di ahoro; tí àwọn ọ̀fàfà sì ń ké lórí rẹ̀.
19 Ṣugbọn ìwọ OLUWA ni ó jọba títí ayé, ìtẹ́ rẹ sì wà láti ìrandíran.
20 Kí ló dé tí o fi gbàgbé wa patapata? Tí o sì kọ̀ wá sílẹ̀ fún ìgbà pípẹ́?
21 Mú wa pada sọ́dọ̀ ara rẹ, OLUWA, kí á lè pada sí ipò wa. Mú àwọn ọjọ́ àtijọ́ wa pada.
22 Ṣé o ti kọ̀ wá sílẹ̀ patapata ni? Àbí o sì tún ń bínú sí wa, inú rẹ kò tíì rọ̀?