1 Iṣẹ́ tí OLUWA rán Joẹli, ọmọ Petueli nìyí:
2 Ẹ gbọ́, ẹ̀yin àgbà, ẹ fetí sílẹ̀, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ilẹ̀ yìí! Ǹjẹ́ irú ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ti ṣẹlẹ̀ rí ní àkókò yín, tabi ní àkókò àwọn baba yín?
3 Ẹ sọ fún àwọn ọmọ yín nípa rẹ̀, kí àwọn náà sọ fún àwọn ọmọ wọn, kí àwọn ọmọ wọn sì sọ fún àwọn ọmọ tiwọn náà.
4 Ohun tí eṣú wẹẹrẹ jẹ kù, ọ̀wọ́ àwọn eṣú ńláńlá jẹ ẹ́. Èyí tí ọ̀wọ́ àwọn eṣú ńláńlá jẹ kù, àwọn eṣú wẹẹrẹ mìíràn jẹ ẹ́, èyí tí àwọn eṣú wẹẹrẹ yìí jẹ kù, àwọn eṣú tí ń jẹ nǹkan run jẹ ẹ́ tán.
5 Ẹ jí lójú oorun, ẹ̀yin ọ̀mùtí, ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń mu waini, nítorí waini tuntun tí a já gbà kúrò lẹ́nu yín.
6 Orílẹ̀-èdè kan ti dojú kọ ilẹ̀ mi, wọ́n lágbára, wọ́n pọ̀, wọn kò sì lóǹkà; eyín wọn dàbí ti kinniun. Ọ̀gàn wọn sì dàbí ti abo kinniun.
7 Wọ́n ti run ọgbà àjàrà mi, wọ́n ti já àwọn ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi, wọ́n ti bó gbogbo èèpo ara rẹ̀, wọ́n ti wó o lulẹ̀, àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì ti di funfun.
8 Ẹ sọkún bí ọmọge tí ó fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora, nítorí ikú àfẹ́sọ́nà ìgbà èwe rẹ̀.
9 A ti dáwọ́ ẹbọ ohun jíjẹ ati ti ohun mímu dúró ní ilé OLUWA, àwọn alufaa tíí ṣe iranṣẹ OLUWA ń ṣọ̀fọ̀.
10 Ilẹ̀ ti gbẹ, ó ń ṣọ̀fọ̀, nítorí a ti run ọkà, àjàrà ti tán, epo olifi sì ń tán lọ.
11 Ẹ banújẹ́, ẹ̀yin àgbẹ̀, ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn ẹ̀yin tí ẹ̀ ń tọ́jú ọgbà àjàrà, nítorí ọkà alikama ati ọkà baali, ati nítorí pé ohun ọ̀gbìn ti ṣègbé.
12 Èso àjàrà ti rọ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì ti ń gbẹ. Igi pomegiranate, igi ọ̀pẹ ati igi ápù, ati gbogbo àwọn igi eléso ti gbẹ, inú ọmọ eniyan kò sì dùn mọ́.
13 Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ sì sọkún, ẹ̀yin alufaa, ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin tí ẹ̀ ǹ ṣiṣẹ́ ní ibi pẹpẹ ìrúbọ. Ẹ̀yin òjíṣẹ́ Ọlọrun mi, ẹ wọlé, kí ẹ sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora sùn, nítorí a ti dáwọ́ ẹbọ ohun jíjẹ ati ẹbọ ohun mímu dúró ní ilé Ọlọrun yín.
14 Ẹ kéde ààwẹ̀, kí ẹ sì pe àpèjọ. Ẹ pe àwọn àgbààgbà, ati gbogbo àwọn tí ń gbé ilẹ̀ náà jọ sí ilé OLUWA Ọlọrun yín, kí ẹ sì kígbe pe OLUWA.
15 Ó ṣe! Ọjọ́ náà ń bọ̀, ọjọ́ OLUWA dé tán! Ọjọ́ náà yóo dé bí ọjọ́ ìparun láti ọ̀dọ̀ Olodumare.
16 A ti gba oúnjẹ lẹ́nu yín, níṣojú yín, bẹ́ẹ̀ ni a gba ayọ̀ ati inú dídùn kúrò ní ilé Ọlọrun wa.
17 Irúgbìn díbàjẹ́ sinu ebè, àwọn ilé ìṣúra ti di ahoro, àwọn àká ti wó lulẹ̀, nítorí kò sí ọkà láti kó sinu wọn mọ́.
18 Àwọn ẹran ọ̀sìn ń kérora, àwọn agbo mààlúù dààmú, nítorí pé kò sí pápá oko fún wọn; àwọn agbo aguntan pàápàá dààmú.
19 Ìwọ ni mo kígbe pè, OLUWA, nítorí iná ti jó gbogbo pápá oko run, ó sì ti jó gbogbo igi oko run.
20 Àwọn ẹranko ìgbẹ́ pàápàá ń kígbe sí ọ, Ọlọrun, nítorí gbogbo àwọn odò ti gbẹ tán, àwọn pápá oko sì ti jóná.
1 Ẹ fun fèrè ní Sioni, ẹ kéde ìdágìrì lórí òkè mímọ́ mi. Kí gbogbo àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí ọjọ́ OLUWA ń bọ̀, ó sì ti dé tán.
2 Yóo jẹ́ ọjọ́ òkùnkùn ati ìbànújẹ́, ọjọ́ ìkùukùu ati òkùnkùn biribiri. Àwọn ọmọ ogun yóo bo gbogbo òkè ńlá, bí ìgbà tí òkùnkùn bá ń ṣú bọ̀. Irú rẹ̀ kò ṣẹlẹ̀ rí ní ìgbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kò sì tún ní ṣẹlẹ̀ mọ́ títí lae.
3 Iná ń jó àjórun níwájú wọn, ahọ́n iná ń yọ lálá lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edẹni níwájú wọn, ṣugbọn lẹ́yìn wọn, ó dàbí aṣálẹ̀ tí ó ti di ahoro, kò sì sí ohun tí yóo bọ́ lọ́wọ́ wọn.
4 Ìrísí wọn dàbí ìrísí ẹṣin, wọ́n sì ń sáré bí ẹṣin tí ń lọ ojú ogun.
5 Ìró wọn dàbí ìró kẹ̀kẹ́ ogun, wọ́n ń bẹ́ lórí àwọn òkè ńlá. Ìró wọn dàbí ìró iná tí ń jó pápá, bí ìgbà tí àwọn alágbára ọmọ ogun múra fún ogun.
6 Ìdààmú bá àwọn orílẹ̀-èdè tí ó bá ti fojú kàn wọ́n, gbogbo ọkàn á rẹ̀wẹ̀sì.
7 Wọ́n ń sáré bí akọni, wọ́n ń fo ògiri bí ọmọ ogun. Wọ́n tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́, ẹnikẹ́ni kò sì yà kúrò ní ọ̀nà tirẹ̀.
8 Wọn kò fi ara gbún ara wọn, olukuluku ń lọ ní ọ̀nà tirẹ̀; wọ́n kọlu àwọn nǹkan ààbò láìní ìdádúró.
9 Wọ́n ń gun odi ìlú, wọ́n ń sáré lórí odi. Wọ́n ń gun orí ilé wọlé, wọ́n gba ojú fèrèsé bẹ́ sinu ọ̀dẹ̀dẹ̀ bí olè.
10 Ilẹ̀ ń mì tìtì níwájú wọn, ọ̀run sì ń wárìrì, oòrùn, òṣùpá ati àwọn ìràwọ̀ ṣókùnkùn.
11 OLUWA sọ̀rọ̀ níwájú àwọn ọmọ ogun rẹ̀, nítorí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ, alágbára ni ẹni tí ń mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ. Ọjọ́ ńlá ati ọjọ́ ẹ̀rù ni ọjọ́ OLUWA! Ta ló lè faradà á?
12 OLUWA ní, “Ẹ yipada sí mi tọkàntọkàn nisinsinyii, pẹlu ààwẹ̀, ẹkún ati ìkẹ́dùn,
13 Ìrònúpìwàdà tòótọ́ ni mò ń fẹ́, kì í ṣe pé kí ẹ fa aṣọ yín ya nìkan.” Ẹ yipada sí OLUWA Ọlọrun yín, nítorí olóore-ọ̀fẹ́ ati aláàánú ni. Kì í yára bínú, Ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀, a sì máa dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji eniyan.
14 Ó ṣeéṣe kí Ọlọrun ṣàánú, kí ó yí ibinu rẹ̀ pada, kí ó sì tú ibukun rẹ̀ sílẹ̀, kí ẹ lè rú ẹbọ ohun jíjẹ ati ẹbọ ohun mímu fún OLUWA Ọlọrun yín.
15 Ẹ fọn fèrè ní òkè Sioni, ẹ kéde ààwẹ̀ kí ẹ sì pe àpéjọ.
16 Ẹ pe gbogbo eniyan jọ, kí ẹ sì ya ìjọ eniyan sí mímọ́. Ẹ pe àwọn àgbààgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọde ati àwọn ọmọ ọwọ́ jọ. Kí ọkọ iyawo jáde láti inú yàrá rẹ̀, kí iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé náà jáde ninu yàrá rẹ̀.
17 Kí àwọn alufaa, àwọn iranṣẹ Ọlọrun, sọkún láàrin ẹnu ọ̀nà àbáwọlé ati pẹpẹ ìrúbọ. Kí wọ́n wí pé “OLUWA, dá àwọn eniyan rẹ sí, má sì sọ ilẹ̀ rẹ di ohun ẹ̀gàn ati ohun ẹ̀sín láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Má jẹ́ kí àwọn eniyan láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù bèèrè pé, ‘Níbo ni Ọlọrun wọn wà?’ ”
18 Nígbà náà ni ara bẹ̀rẹ̀ sí ta OLUWA nítorí ilẹ̀ rẹ̀, ó sì ṣàánú fún àwọn eniyan rẹ̀.
19 OLUWA dá àwọn eniyan rẹ̀ lóhùn pé, “Wò ó! N óo fun yín ní ọkà, waini ati òróró, ẹ óo ní ànítẹ́rùn. N kò ní sọ yín di ẹni ẹ̀gàn láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
20 N óo kó àwọn eṣú láti ìhà àríwá jìnnà kúrò lọ́dọ̀ yín, n óo lé wọn lọ sinu aṣálẹ̀ níbi tí kò sí nǹkankan. N óo lé àwọn tí wọ́n wà níwájú lọ sí inú òkun, ní apá ìlà oòrùn, n óo sì lé àwọn tí wọ́n wà lẹ́yìn lọ sí inú òkun, ní apá ìwọ̀ oòrùn. Òkú wọn yóo máa rùn; n óo pa wọ́n run nítorí ibi ńlá tí wọ́n ṣe.
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀, jẹ́ kí inú rẹ máa dùn, kí o sì máa yọ̀, nítorí OLUWA ti ṣe nǹkan ńlá.
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin ẹranko inú igbó, nítorí ewéko gbogbo ni ó tutù, igi gbogbo ti so èso, igi ọ̀pọ̀tọ́ ati ọgbà àjàrà sì ti so jìnwìnnì.
23 “Ẹ máa yọ̀, ẹ̀yin ará Sioni, kí inú yín máa dùn ninu OLUWA Ọlọrun yín; nítorí ó ti da yín láre, ó ti fun yín ní àkọ́rọ̀ òjò, ó ti rọ ọpọlọpọ òjò fun yín: ati òjò àkọ́rọ̀, ati àrọ̀kẹ́yìn òjò, gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀.
24 Gbogbo ibi ìpakà ni yóo kún fún ọkà, ìkòkò waini ati ti òróró yín yóo kún àkúnwọ́sílẹ̀.
25 Gbogbo ohun tí ẹ pàdánù ní àwọn ọdún tí àwọn ọmọ ogun mi tí mo rán si yín ti jẹ oko yín; ati èyí tí eṣú wẹẹrẹ jẹ, ati èyí tí eṣú ńláńlá jẹ, gbogbo rẹ̀ ni n óo dá pada fun yín.
26 Ẹ óo jẹ oúnjẹ àjẹyó ati àjẹtẹ́rùn, ẹ óo sì yin orúkọ OLUWA Ọlọrun yín, tí ó ṣe ohun ìyanu ńlá fun yín, ojú kò sì ní ti àwọn eniyan mi mọ́ lae.
27 Ẹ óo mọ̀ pé mo wà láàrin Israẹli; ati pé èmi OLUWA ni Ọlọrun yín, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi mọ́. Ojú kò sì ní ti àwọn eniyan mi mọ́ lae.
28 “Lẹ́yìn náà, nígbà tí ó bá yá, n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára gbogbo eniyan, àwọn ọmọkunrin ati àwọn ọmọbinrin yín yóo máa sọ àsọtẹ́lẹ̀, àwọn àgbààgbà yín yóo máa lá àlá, àwọn ọdọmọkunrin yín yóo sì máa ríran.
29 Bákan náà, nígbà tí àkókò bá tó, n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára àwọn iranṣẹkunrin ati àwọn iranṣẹbinrin yín.
30 “Ìtàjẹ̀sílẹ̀ yóo pọ̀, n óo sì fi iná, ati òpó èéfín sí ojú ọ̀run, ati sórí ilẹ̀ ayé; yóo jẹ́ ìkìlọ̀ fun yín.
31 Oòrùn yóo ṣókùnkùn, òṣùpá yóo pọ́n rẹ̀bẹ̀tẹ̀ bí ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ OLUWA tí ó lẹ́rù tó dé.
32 Ṣugbọn gbogbo àwọn tí wọ́n bá ké pe orúkọ OLUWA ni a óo gbàlà. Àwọn kan yóo sá àsálà ní òkè Sioni, ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti sọ, àwọn tí OLUWA pè yóo sì wà lára àwọn tí wọn yóo sá àsálà.
1 “Wò ó! Nígbà tó bá yá, tí mo bá dá ire Juda ati ti Jerusalẹmu pada,
2 n óo kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí àfonífojì Jehoṣafati, n óo sì dá wọn lẹ́jọ́ níbẹ̀; nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli, àwọn eniyan mi. Wọ́n ti fọ́n wọn káàkiri sí ààrin àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì ti pín ilẹ̀ mi.
3 Wọ́n ti ṣẹ́ gègé lórí àwọn eniyan mi, wọ́n ti ta àwọn ọmọkunrin wọn, wọ́n fi owó wọn san owó aṣẹ́wó, wọ́n sì ta àwọn ọmọbinrin wọn, wọ́n fi owó wọn ra ọtí waini.
4 “Kí ni mo fi ṣe yín rí, ẹ̀yin ilẹ̀ Tire, ati ilẹ̀ Sidoni ati gbogbo agbègbè Filistini? Ṣé ẹ̀ ń gbẹ̀san nǹkankan lára mi ni? Bí ó bá jẹ́ pé ẹ̀ ń gbẹ̀san nǹkankan ni, n óo da ẹ̀san tí ẹ̀ ń gbà le yín lórí kíákíá;
5 nítorí ẹ ti kó fadaka ati wúrà ati àwọn ìṣúra mi olówó iyebíye lọ sí ilé oriṣa yín.
6 Ẹ ta àwọn ará Juda ati àwọn ará Jerusalẹmu fún àwọn ará Giriki, ẹ kó wọn jìnnà réré sí ilẹ̀ wọn.
7 Ṣugbọn nisinsinyii, n óo gbé wọn dìde níbi tí ẹ tà wọ́n sí, n óo sì gbẹ̀san ìwà yín lára ẹ̀yin alára.
8 N óo ta àwọn ọmọ yín ọkunrin ati àwọn ọmọ yín obinrin lẹ́rú fún àwọn ará Juda. Wọn yóo sì tà wọ́n fún àwọn ará Sabea, orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà réré; nítorí OLUWA ni ó sọ bẹ́ẹ̀.”
9 Ẹ kéde èyí láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè. Ẹ múra ogun, ẹ rú àwọn akọni sókè. Kí gbogbo àwọn ọmọ ogun súnmọ́ tòsí, ogun yá!
10 Ẹ fi irin ọkọ́ yín rọ idà, ẹ fi dòjé yín rọ ọ̀kọ̀, kí àwọn tí wọn kò lágbára wí pé, “Ọmọ ogun ni mí.”
11 Ẹ yára, ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè tí ẹ wà ní àyíká, ẹ parapọ̀ níbẹ̀. Rán àwọn ọmọ ogun rẹ wá, OLUWA.
12 Jẹ́ kí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè dìde, kí wọ́n wá sí àfonífojì Jehoṣafati, nítorí níbẹ̀ ni n óo ti ṣe ìdájọ́ gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká.
13 Ẹ ti dòjé bọ oko, nítorí àkókò ìkórè ti tó, ẹ lọ fún ọtí waini nítorí ibi ìfúntí ti kún. Ìkòkò ọtí ti kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìkà wọ́n pọ̀.
14 Ogunlọ́gọ̀ wà ní àfonífojì ìdájọ́, nítorí ọjọ́ OLUWA kù sí dẹ̀dẹ̀ níbẹ̀.
15 Oòrùn ati òṣùpá ti ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ kò sì tan ìmọ́lẹ̀ mọ́.
16 OLUWA kígbe láti Sioni, ó sọ̀rọ̀ láti Jerusalẹmu; ọ̀run ati ayé mì tìtì, ṣugbọn OLUWA ni ààbò fún àwọn eniyan rẹ̀, òun ni ibi ààbò fún Israẹli.
17 “Israẹli, o óo mọ̀ pé èmi ni OLUWA, Ọlọrun rẹ, èmi ni mò ń gbé Sioni, òkè mímọ́ mi. Jerusalẹmu yóo di ìlú mímọ́, àwọn àjèjì kò sì ní ṣẹgun mọ́.
18 “Nígbà náà, àwọn òkè ńlá yóo kún fún èso àjàrà, agbo mààlúù yóo sì pọ̀ lórí àwọn òkè kéékèèké. Gbogbo àwọn odò Juda yóo kún fún omi. Odò kan yóo bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn láti ilé OLUWA, yóo sì bomi rin àfonífojì Ṣitimu.
19 “Ijipti yóo di aṣálẹ̀; Edomu yóo sì di ẹgàn, nítorí ìwà ipá tí wọ́n hù sí àwọn ará Juda, nítorí wọ́n ti pa àwọn aláìṣẹ̀ ní ilẹ̀ wọn.
20 Ṣugbọn àwọn eniyan yóo máa gbé ilẹ̀ Juda títí lae, wọn óo sì máa gbé ìlú Jerusalẹmu láti ìrandíran.
21 N óo gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn tí ẹ pa, n kò sì ní dá ẹlẹ́bi sí, nítorí èmi OLUWA ni mò ń gbé Sioni.”