1

1 Ọ̀rọ̀ OLUWA nìyí; tí a kọ sinu ìwé ìran tí Nahumu ará Elikoṣi rí nípa ìlú Ninefe.

2 OLUWA tíí jowú tíí sìí máa gbẹ̀san ni Ọlọrun. OLUWA a máa gbẹ̀san, a sì máa bínú. OLUWA a máa gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, a sì máa fi ìrúnú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ọ̀tá rẹ̀.

3 OLUWA kì í tètè bínú; ó lágbára lọpọlọpọ, kì í sìí dá ẹni tí ó bá jẹ̀bi láre. Ipa ọ̀nà rẹ̀ wà ninu ìjì ati ẹ̀fúùfù líle, awọsanma sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4 Ó bá òkun wí, ó mú kí ó gbẹ, ó sì mú kí gbogbo odò gbẹ pẹlu; koríko ilẹ̀ Baṣani ati ti òkè Kamẹli gbẹ, òdòdó ilẹ̀ Lẹbanoni sì rẹ̀.

5 Àwọn òkè ńláńlá mì tìtì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì yọ́. Ilẹ̀ di asán níwájú rẹ̀, ayé ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀ di òfo.

6 Bí ó bá ń bínú ta ló lè dúró? Ta ló lè farada ibinu gbígbóná rẹ̀? Ìrúnú rẹ̀ a máa ru jáde bí ahọ́n iná, a sì máa fọ́ àwọn àpáta níwájú rẹ̀.

7 OLUWA ṣeun, òun ni ibi ààbò ní ọjọ́ ìdààmú; ó sì mọ àwọn tí wọn ń sálọ sọ́dọ̀ rẹ̀ fún ààbò.

8 Bí odò tí ó kún bo bèbè rẹ̀ ni yóo ṣe mú ìparun bá àwọn ọ̀tá rẹ̀; yóo sì lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀ bọ́ sí inú òkùnkùn.

9 Èrò ibi wo ni ẹ̀ ń gbà sí OLUWA? Yóo wulẹ̀ pa yín run patapata ni; kò sì sí ẹni tí OLUWA yóo gbẹ̀san lára rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan tí yóo lè ṣẹ̀ ẹ́ lẹẹkeji.

10 Wọn yóo jóná bí igbó ẹlẹ́gùn-ún tí ó dí, àní bíi koríko gbígbẹ.

11 Ṣebí ọ̀kan ninu yín ni ó ń gbìmọ̀ burúkú sí OLUWA, tí ó sì ń fúnni ní ìmọ̀ràn burúkú?

12 OLUWA wí pé: “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará Siria lágbára, tí wọ́n sì pọ̀, a óo pa wọ́n run, wọn yóo sì parẹ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti jẹ ẹ̀yin ọmọ Juda níyà tẹ́lẹ̀, n kò ní jẹ yín níyà mọ́.

13 N óo bọ́ àjàgà Asiria kúrò lọ́rùn yín, n óo sì já ìdè yín.”

14 OLUWA ti pàṣẹ nípa Asiria, pé: “A kò ní ranti orúkọ rẹ mọ́, ìwọ ilẹ̀ Asiria, n óo run àwọn ère tí ẹ̀yin ará Asiria gbẹ́, ati àwọn tí ẹ dà, tí wọ́n wà ní ilé oriṣa rẹ, n óo gbẹ́ ibojì rẹ, nítorí ẹlẹ́gbin ni ọ́.”

15 Wo ẹsẹ̀ ẹni tí ó ń mú ìyìn rere wá lórí àwọn òkè ńláńlá, ẹni tí ń kéde alaafia! Ẹ máa ṣe àwọn àjọ̀dún yín, ẹ̀yin ará Juda, kí ẹ sì san àwọn ẹ̀jẹ́ yín, nítorí ẹni ibi kò ní gbógun tì yín mọ́, a ti pa á run patapata.

2

1 Atúniká ti gbógun tì ọ́, ìwọ Ninefe. Yan eniyan ṣọ́ ibi ààbò; máa ṣọ́nà, di àmùrè rẹ, kí o sì múra ogun.

2 (Nítorí OLUWA ti ṣetán láti dá ògo Jakọbu pada bí ògo Israẹli, nítorí àwọn tí wọn ń kóni lẹ́rú ti kó wọn, wọ́n sì ti ba àwọn ẹ̀ka wọn jẹ́.)

3 Pupa ni asà àwọn akọni rẹ̀, ẹ̀wù pupa ni àwọn ọmọ ogun rẹ̀ wọ̀ Kẹ̀kẹ́ ogun wọn ń kọ mànà bí ọwọ́ iná; nígbà tí wọ́n tò wọ́n jọ, àwọn ẹṣin wọn ń yan.

4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun ń dà wọ ìgboro pẹlu ariwo, wọ́n ń sáré sókè sódò ní gbàgede; wọ́n mọ́lẹ̀ yòò bí iná ìtùfù, wọ́n ń kọ mànà bí mànàmáná.

5 Ó pe àwọn ọ̀gágun rẹ̀ jọ, wọ́n sì ń fẹsẹ̀ kọ bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n yára lọ sí ibi odi, wọ́n sì fi asà dira ogun.

6 Àwọn ìlẹ̀kùn odò ṣí sílẹ̀, ìdàrúdàpọ̀ wà láàfin.

7 A tú ayaba sí ìhòòhò, a sì mú un lọ sí ìgbèkùn, àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀ ń dárò rẹ̀, wọ́n káwọ́ lérí, wọ́n ń rin bí oriri.

8 Ìlú Ninefe dàbí adágún odò tí omi rẹ̀ ti ṣàn lọ. Wọ́n ń kígbe pé, “Ẹ dúró! Ẹ dúró!” Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yíjú pada.

9 Ẹ kó fadaka, ẹ kó wúrà! Ìlú náà kún fún ìṣúra, ati àwọn nǹkan olówó iyebíye.

10 A ti pa Ninefe run! Ó ti dahoro! Ọkàn àwọn eniyan ti dàrú, orúnkún wọn ń gbọ̀n pẹ̀pẹ̀, ìrora dé bá ọpọlọpọ, gbogbo ojú wọn sì rẹ̀wẹ̀sì.

11 Níbo ni ìlú tí ó dàbí ihò àwọn kinniun wà? Tí ó rí bí ibùgbé àwọn ọ̀dọ́ kinniun? Ibi tí kinniun ń gbé oúnjẹ rẹ̀ lọ, tí àwọn ọmọ rẹ̀ wà, tí kò sí ẹni tí ó lè dà wọ́n láàmú?

12 Akọ kinniun a máa fa ẹran ya fún àwọn ọmọ rẹ̀, a sì máa lọ́ ẹran lọ́rùn pa fún àwọn abo rẹ̀; a máa kó ẹran tí ó bá pa ati èyí tí ó fàya sinu ihò rẹ̀.

13 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Wò ó! Mo ti dójú lé ọ. N óo dáná sun kẹ̀kẹ́ ogun rẹ, n óo sì fi idà pa àwọn ọmọ ogun rẹ. Gbogbo ohun tí o ti gbà lọ́wọ́ àwọn ẹlòmíràn ni n óo gbà pada lọ́wọ́ rẹ; a kò sì ní gbọ́ ohùn àwọn iranṣẹ rẹ mọ́.”

3

1 Ìlú tí ń ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ gbé! Ìlú tí ó kún fún irọ́ ati ìkógun, tí àwọn adigunjalè kò fi ìgbà kan dáwọ́ dúró níbẹ̀!

2 Pàṣán ń ró, ẹṣin ń yan, kẹ̀kẹ́ ogun ń pariwo!

3 Àwọn ẹlẹ́ṣin ti múra ìjà pẹlu idà ati ọ̀kọ̀ tí ń kọ mànà. Ọpọlọpọ ni wọ́n ti pa sílẹ̀, òkítì òkú kúnlẹ̀ lọ kítikìti; òkú sùn lọ bẹẹrẹ láìníye, àwọn eniyan sì ń kọlu àwọn òkú bí wọn tí ń lọ!

4 Nítorí ọpọlọpọ ìwà àgbèrè Ninefe, tí wọ́n fanimọ́ra, ṣugbọn tí wọ́n kún fún òògùn olóró, ni gbogbo ìjìyà yìí ṣe dé bá a; nítorí ó ń fi ìwà àgbèrè rẹ̀ tan àwọn orílẹ̀-èdè jẹ, ó sì ń fi òògùn rẹ̀ mú àwọn eniyan.

5 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní: “Wò ó! Mo ti gbógun tì ọ́, Ninefe, n óo ká aṣọ kúrò lára rẹ, n óo fi bò ọ́ lójú; n óo tú ọ sí ìhòòhò lójú àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn. Àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn yóo rí ìhòòhò rẹ ojú yóo sì tì ọ́.

6 N óo mú ẹ̀gbin bá ọ n óo fi àbùkù kàn ọ́; n óo sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà ati ẹni àpéwò.

7 Ẹnu yóo ya gbogbo àwọn tí ó bá wò ọ́, wọn yóo máa wí pé: ‘Ninefe ti di ahoro; ta ni yóo dárò rẹ̀? Níbo ni n óo ti rí olùtùnú fún ọ?’ ”

8 Ṣé ìwọ Ninefe sàn ju ìlú Tebesi lọ, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ odò Naili, tí omi yíká, tí ó fi òkun ṣe ààbò, tí ó sì fi omi ṣe odi rẹ̀?

9 Etiopia ati Ijipti ni agbára rẹ̀ tí kò lópin; Puti ati Libia sì ni olùrànlọ́wọ́ rẹ̀.

10 Sibẹsibẹ àwọn ọ̀tá kó o lọ sí ìgbèkùn, wọ́n ṣán àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀, wọ́n pa wọ́n ní ìpakúpa ní gbogbo àwọn ìkóríta wọn. Wọ́n ṣẹ́ gègé lórí àwọn ọlọ́lá ibẹ̀, wọ́n sì fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ de àwọn eniyan pataki wọn.

11 Ninefe, ìwọ pàápàá yóo mu ọtí yó, o óo máa ta gbọ̀n- ọ́ngbọ̀n-ọ́n; o óo sì máa wá ààbò nítorí àwọn ọ̀tá rẹ.

12 Gbogbo ibi ààbò rẹ yóo dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí àkọ́so èso rẹ̀ pọ́n bí wọn bá ti gbọ̀n ọ́n, bẹ́ẹ̀ ni èso rẹ̀ yóo máa jábọ́ sí ẹnu ẹni tí yóo jẹ ẹ́.

13 Wò ó! Àwọn ọmọ ogun rẹ dàbí obinrin! Gbogbo ẹnubodè rẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ; iná sì ti jó gbogbo ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn bodè rẹ.

14 Ẹ pọn omi sílẹ̀ de àkókò tí ogun yóo dótì yín, ẹ ṣe ibi ààbò yín kí ó lágbára; ẹ lọ sí ibi ilẹ̀ alámọ̀, ẹ gún amọ̀, kí ẹ fi ṣe bíríkì!

15 Ibẹ̀ ni iná yóo ti jó yín run, idà yóo pa yín lọ bí eṣú. Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ pọ̀ bí eṣú!

16 O ti wá kún àwọn oníṣòwò rẹ, wọ́n sì pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ! Ṣugbọn wọ́n ti na ìyẹ́ wọn bí eṣú, wọ́n sì fò lọ.

17 Àwọn olórí yín dàbí tata, àwọn akọ̀wé yín sì dàbí ọ̀wọ́ eṣú, tíí bà sórí odi nígbà òtútù, nígbà tí oòrùn bá yọ wọn a fò lọ; kò sì ní sí ẹni tí yóo mọ ibi tí wọ́n lọ.

18 Àwọn olùṣọ́ rẹ ń sùn, ìwọ ọba Asiria, àwọn ọlọ́lá rẹ sì ń tòògbé; Àwọn eniyan rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè, láìsí ẹni tí yóo gbá wọn jọ.

19 Kò sí ẹni tí yóo wo ọgbẹ́ rẹ sàn nítorí egbò rẹ pọ̀. Àwọn tí wọ́n bá gbọ́ ìròyìn rẹ yóo pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí, nítorí kò sí ẹni tí kò tíì faragbá ninu ìwà burúkú rẹ.