1 Àwọn orin tí ó dùn jùlọ tí Solomoni kọ nìwọ̀nyí:
2 Wá fi ẹnu kò mí lẹ́nu, nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ọtí waini lọ.
3 Òróró ìpara rẹ ní òórùn dídùn, orúkọ rẹ dàbí òróró ìkunra tí a tú jáde; nítorí náà ni àwọn ọmọbinrin ṣe fẹ́ràn rẹ.
4 Fà mí mọ́ra, jẹ́ kí á ṣe kíá, ọba ti mú mi wọ yàrá rẹ̀. Inú wa yóo máa dùn, a óo sì máa yọ̀ nítorí rẹ a óo gbé ìfẹ́ rẹ ga ju ọtí waini lọ; abájọ tí gbogbo àwọn obinrin ṣe fẹ́ràn rẹ!
5 Ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu, mo dúdú lóòótọ́, ṣugbọn mo lẹ́wà, mo dàbí àgọ́ Kedari, mo rí bí aṣọ títa tí ó wà ní ààfin Solomoni.
6 Má wò mí tìka-tẹ̀gbin, nítorí pé mo dúdú, oòrùn tó pa mí ló ṣe àwọ̀ mi bẹ́ẹ̀. Àwọn ọmọ ìyá mi lọkunrin bínú sí mi, wọ́n fi mí ṣe olùtọ́jú ọgbà àjàrà, ṣugbọn n kò tọ́jú ọgbà àjàrà tèmi alára.
7 Sọ fún mi, ìwọ ẹni tí ọkàn mi fẹ́: níbo ni ò ó máa ń da àwọn ẹran rẹ lọ jẹko? Níbo ni wọ́n ti ń sinmi, nígbà tí oòrùn bá mú? Kí n má baà máa wá ọ kiri, láàrin agbo ẹran àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ?
8 Ìwọ tí o lẹ́wà jùlọ láàrin àwọn obinrin, bí o kò bá mọ ibẹ̀, ṣá máa tẹ̀lé ipa agbo ẹran. Jẹ́ kí àwọn ọmọ ẹran rẹ máa jẹko lẹ́bàá àgọ́ àwọn olùṣọ́-aguntan.
9 Olólùfẹ́ mi, mo fi ọ́ wé akọ ẹṣin tí ń fa kẹ̀kẹ́ ogun Farao.
10 Nǹkan ọ̀ṣọ́ mú kí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́wà, ẹ̀gbà ọrùn sì mú kí ọrùn rẹ lẹ́wà.
11 A óo ṣe àwọn nǹkan ọ̀ṣọ́ wúrà, tí a fi fadaka ṣe ọnà sí lára fún ọ.
12 Nígbà tí ọba rọ̀gbọ̀kú lórí ìjókòó rẹ̀, turari mi ń tú òórùn dídùn jáde.
13 Olùfẹ́ mi dàbí àpò òjíá, bí ó ti sùn lé mi láyà.
14 Olùfẹ́ mi dàbí ìdì òdòdó igi Sipirẹsi, ninu ọgbà àjàrà Engedi.
15 Wò ó! O mà dára o, olólùfẹ́ mi; o lẹ́wà pupọ. Ojú rẹ tutù bíi ti àdàbà.
16 Háà, o mà dára o! Olùfẹ́ mi, o lẹ́wà gan-an ni. Ewéko tútù ni yóo jẹ́ ibùsùn wa.
17 Igi Kedari ni òpó ilé wa, igi firi sì ni ọ̀pá àjà ilé wa.
1 Òdòdó Ṣaroni ni mí, ati òdòdó Lílì tí ó wà ninu àfonífojì.
2 Bí òdòdó lílì ti rí láàrin ẹ̀gún, ni olólùfẹ́ mi rí láàrin àwọn ọmọge.
3 Bí igi ápù ti rí láàrin àwọn igi igbó, ni olùfẹ́ mí rí láàrin àwọn ọmọkunrin. Pẹlu ìdùnnú ńlá ni mo fi jókòó lábẹ́ òjìji rẹ̀, èso rẹ̀ sì dùn lẹ́nu mi.
4 Ó mú mi wá sí ilé àsè ńlá, ìfẹ́ ni ọ̀págun rẹ̀ lórí mi.
5 Fún mi ni èso àjàrà gbígbẹ jẹ, kí ara mi mókun, fún mi ní èso ápù jẹ kí ara tù mí, nítorí pé, àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.
6 Ó wù mí kí ọwọ́ òsì rẹ̀ wà ní ìgbèrí mi, kí ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fà mí mọ́ra.
7 Mo kìlọ̀ fun yín, ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu, ní orúkọ egbin, ati ti àgbọ̀nrín pé, ẹ kò gbọdọ̀ jí ìfẹ́ títí yóo fi wù ú láti jí.
8 Mo gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi, wò ó! Ó ń bọ̀, ó ń fò lórí àwọn òkè ńlá, ó sì ń bẹ́ lórí àwọn òkè kéékèèké.
9 Olólùfẹ́ mi dàbí egbin, tabi ọ̀dọ́ akọ àgbọ̀nrín. Wò ó! Ó dúró lẹ́yìn ògiri ilé wa, ó ń yọjú lójú fèrèsé, ó ń yọjú níbi fèrèsé kékeré tí ó wà lókè.
10 Olùfẹ́ mi bá mi sọ̀rọ̀, ó wí fún mi pé, “Dìde, olùfẹ́ mi, arẹwà mi, jẹ́ kí á máa lọ.”
11 Àkókò òtútù ti lọ, òjò sì ti dáwọ́ dúró.
12 Àwọn òdòdó ti hù jáde, àkókò orin kíkọ ti tó, a sì ti ń gbọ́ ohùn àwọn àdàbà ní ilẹ̀ wa.
13 Àwọn igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ń so èso, àjàrà tí ń tanná, ìtànná wọn sì ń tú òórùn dídùn jáde. Dìde, olùfẹ́ mi, arẹwà mi, jẹ́ kí á máa lọ.
14 Àdàbà mi, tí ó wà ninu pàlàpálá òkúta, ní ibi kọ́lọ́fín òkúta, jẹ́ kí n rójú rẹ, kí n gbọ́ ohùn rẹ, nítorí ohùn rẹ dùn, ojú rẹ sì dára.
15 Mú àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ wọ̀n-ọn-nì, àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ kéékèèké tí wọn ń ba ọgbà àjàrà jẹ́, nítorí ọgbà àjàrà wa tí ń tanná.
16 Olùfẹ́ mi ni ó ni mí, èmi ni mo sì ni olùfẹ́ mi, ó ń da àwọn ẹran rẹ̀, wọn ń jẹko láàrin òdòdó lílì.
17 Tún pada wá! Olùfẹ́ mi, títí ilẹ̀ yóo fi mọ́, tí òjìji kò ní sí mọ́. Pada wá bí egbin ati akọ àgbọ̀nrín, lórí àwọn òkè págunpàgun.
1 Mo wá ẹni tí ọkàn mi fẹ́, lórí ibùsùn mi lálẹ́, mo wá a, ṣugbọn n kò rí i; mo pè é, ṣugbọn kò dáhùn.
2 N óo dìde nisinsinyii, n óo sì lọ káàkiri ìlú, n óo wá ẹni tí ọkàn mi fẹ́, ní gbogbo òpópónà ati ní gbogbo gbàgede. Mo wá a ṣugbọn n kò rí i.
3 Àwọn aṣọ́de rí mi, bí wọ́n ṣe ń lọ káàkiri ìlú. Mo bèèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́?”
4 Mo fẹ́rẹ̀ má tíì kúrò lọ́dọ̀ wọn, ni mo bá rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́. Mo dì í mú, n kò sì jẹ́ kí ó lọ, títí tí mo fi mú un dé ilé ìyá mi, ninu ìyẹ̀wù ẹni tí ó lóyún mi.
5 Mò ń kìlọ̀ fun yín, ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu, mo fi egbin ati àgbọ̀nrín inú igbó búra, pé, ẹ kò gbọdọ̀ jí olùfẹ́ mi, títí yóo fi wù ú láti jí.
6 Kí ló ń jáde bọ̀ láti inú aṣálẹ̀ yìí, tí ó dàbí òpó èéfín, tí ó kún fún òórùn dídùn òjíá ati turari, pẹlu òórùn dídùn àtíkè àwọn oníṣòwò?
7 Wò ó! Solomoni ni wọ́n ń gbé bọ̀, lórí ìtẹ́ rẹ̀, ọgọta akọni ọkunrin, lára àwọn akọni Israẹli, ni ó yí ìtẹ́ rẹ̀ ká.
8 Gbogbo wọn dira ogun pẹlu idà, akọni sì ni wọ́n lójú ogun. Olukuluku dira pẹlu idà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, nítorí ìdágìrì ọ̀gànjọ́.
9 Igi Lẹbanoni ni Solomoni fi ṣe ìtẹ́ rẹ̀.
10 Ó fi fadaka ṣe àwọn ẹsẹ̀ ìjókòó rẹ̀, ó fi wúrà ṣe ẹ̀yìn rẹ̀, Aṣọ elése-àlùkò tí àwọn ọmọbinrin Jerusalẹmu hun ni ó fi ṣe tìmùtìmù ìjókòó rẹ̀.
11 Ẹ jáde lọ, ẹ̀yin ọmọbinrin Sioni, ẹ lọ wo Solomoni ọba, pẹlu adé tí ìyá rẹ̀ fi dé e lórí, ní ọjọ́ igbeyawo, ní ọjọ́ ìdùnnú ati ọjọ́ ayọ̀ rẹ̀.
1 Wò ó! O dára gan-an ni, olólùfẹ́ mi, ẹwà rẹ pọ̀. Ẹyinjú rẹ dàbí ti àdàbà lábẹ́ ìbòjú rẹ, irun orí rẹ dàbí ọ̀wọ́ ewúrẹ́, tí wọn ń sọ̀kalẹ̀ láti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Gileadi.
2 Eyín rẹ dàbí ọ̀wọ́ aguntan tí wọn ṣẹ̀ṣẹ̀ gé irun wọn, tí wọn wá fọ̀; gbogbo wọn gún régé, Kò sí ọ̀kan kan tí ó yọ ninu wọn.
3 Ètè rẹ dàbí òwú pupa; ẹnu rẹ fanimọ́ra, ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ ń dán bí ìlàjì èso Pomegiranate, lábẹ́ ìbòjú rẹ.
4 Ọrùn rẹ dàbí ilé ìṣọ́ Dafidi, tí a kọ́ fún ihamọra, ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn rẹ dàbí ẹgbẹrun (1000) asà tí a kó kọ́, bí apata àwọn akọni jagunjagun tí a kó jọ.
5 Ọmú rẹ mejeeji dàbí ọmọ àgbọ̀nrín meji, tí wọn jẹ́ ìbejì, tí wọn ń jẹko láàrin òdòdó lílì.
6 N óo wà lórí òkè òjíá, ati lórí òkè turari, títí ilẹ̀ yóo fi mọ́, tí òkùnkùn yóo sì lọ.
7 O dára gan-an ni, olùfẹ́ mi! O dára dára, o ò kù síbìkan, kò sí àbààwọ́n kankan lára rẹ.
8 Máa bá mi bọ̀ láti òkè Lẹbanoni, iyawo mi, máa bá mi bọ̀ láti òkè Lẹbanoni. Kúrò ní ṣóńṣó òkè Amana, kúrò lórí òkè Seniri ati òkè Herimoni, kúrò ninu ihò kinniun, ati ibi tí àwọn ẹkùn ń gbé.
9 O ti kó sí mi lẹ́mìí, arabinrin mi, iyawo mi, ẹ̀ẹ̀kan náà tí o ti ṣíjú wò mí, pẹlu nǹkan ọ̀ṣọ́ tí ó wà lọ́rùn rẹ, ni o ti kó sí mi lórí.
10 Ìfẹ́ rẹ ti dùn tó! Arabinrin mi, iyawo mi, ìfẹ́ rẹ dùn ju waini lọ. Òróró ìkunra rẹ dára ju turari-kí-turari lọ.
11 Oyin ní ń kán ní ètè rẹ, iyawo mi, wàrà ati oyin wà lábẹ́ ahọ́n rẹ, òórùn dídùn aṣọ rẹ dàbí òórùn Lẹbanoni.
12 Arabinrin mi dàbí ọgbà tí a ti ti ìlẹ̀kùn rẹ̀. Ọgbà tí a tì ni iyawo mi; àní orísun omi tí a tì ni ọ́.
13 Àwọn ohun ọ̀gbìn inú rẹ tí ń sọ dàbí ọgbà pomegiranate, tí ó kún fún èso tí ó dára jùlọ, àwọn bíi igi hena ati nadi;
14 igi nadi ati Safironi, Kalamusi ati Sinamoni, pẹlu oríṣìíríṣìí igi turari, igi òjíá, ati ti aloe, ati àwọn ojúlówó turari tí òórùn wọn dára jùlọ.
15 Ọgbà tí ó ní orísun omi ni ọ́, kànga omi tútù, àní, odò tí ń ṣàn, láti òkè Lẹbanoni.
16 Dìde, ìwọ afẹ́fẹ́ ìhà àríwá, máa bọ̀, ìwọ afẹ́fẹ́ ìhà gúsù! Fẹ́ sórí ọgbà mi, kí òórùn dídùn rẹ̀ lè tàn káàkiri. Kí olùfẹ́ mi wá sinu ọgbà rẹ̀, kí ó sì jẹ èso tí ó bá dára jùlọ.
1 Mo wọ inú ọgbà mi, arabinrin mi, iyawo mi. Mo kó òjíá ati àwọn turari olóòórùn dídùn mi jọ, mo jẹ afárá oyin mi, pẹlu oyin inú rẹ̀, mo mu waini mi ati wàrà mi. Ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, ẹ jẹ, kí ẹ sì mu, ẹ mu àmutẹ́rùn, ẹ̀yin olùfẹ́.
2 Mo sùn ṣugbọn ọkàn mi kò sùn. Ẹ gbọ́! Olùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn. Ṣílẹ̀kùn fún mi, arabinrin mi, olùfẹ́ mi, àdàbà mi, olùfẹ́ mi tí ó péye, nítorí pé, ìrì ti mú kí orí mi tutù, gbogbo irun mi ti rẹ, fún ìrì alẹ́.
3 Mo ti bọ́ra sílẹ̀, báwo ni mo ṣe lè tún múra? Mo ti fọ ẹsẹ̀ mi, báwo ni mo ṣe lè tún dọ̀tí rẹ̀?
4 Olùfẹ́ mi gbọ́wọ́ lé ìlẹ̀kùn, ọkàn mi sì kún fún ayọ̀.
5 Mo dìde, mo ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi, gbogbo ọwọ́ mi kún fún òjíá, òróró òjíá sì ń kán ní ìka mi sára kọ́kọ́rọ́ ìlẹ̀kùn.
6 Mo ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi, ṣugbọn ó ti yipada, ó ti lọ. Mo fẹ́rẹ̀ dákú, nígbà tí ó sọ̀rọ̀, mo wá a, ṣugbọn n kò rí i, mo pè é, ṣugbọn kò dáhùn.
7 Àwọn aṣọ́de rí mi bí wọ́n ti ń rìn káàkiri ìlú; wọ́n lù mí, wọ́n ṣe mí léṣe, wọ́n sì gba ìborùn mi.
8 Mo rọ̀ yín, ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu, bí ẹ bá rí olùfẹ́ mi, ẹ bá mi sọ fún un pé: Àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.
9 Kí ni olùfẹ́ tìrẹ fi dára ju ti àwọn yòókù lọ? Ìwọ arẹwà jùlọ láàrin àwọn obinrin? Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju ti àwọn yòókù lọ? Tí o fi ń kìlọ̀ fún wa bẹ́ẹ̀?
10 Olùfẹ́ mi lẹ́wà pupọ, ó sì pupa, ó yàtọ̀ láàrin ẹgbaarun (10,000) ọkunrin.
11 Orí rẹ̀ dàbí ojúlówó wúrà, irun rẹ̀ lọ́, ó ṣẹ́ léra wẹ́lẹ́wẹ́lẹ́ ó dúdú bíi kóró iṣin.
12 Ojú rẹ̀ dàbí àwọn àdàbà etí odò, tí a fi wàrà wẹ̀, tí wọ́n tò sí bèbè odò.
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ dàbí ebè òdòdó olóòórùn dídùn, tí ń tú òórùn dídùn jáde. Ètè rẹ̀ dàbí òdòdó lílì, tí òróró òjíá ń kán níbẹ̀.
14 Ọwọ́ rẹ̀ dàbí ọ̀pá wúrà, tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí lára. Ara rẹ̀ dàbí eyín erin tí ń dán tí a fi òkúta safire bò.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí òpó alabasita tí a gbé ka orí ìtẹ́lẹ̀ wúrà. Ìrísí rẹ̀ dàbí òkè Lẹbanoni, ó rí gbọ̀ngbọ̀nràn bí igi Kedari.
16 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ dùn, àfi bí oyin, ó wuni lọpọlọpọ. Ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu, òun ni olùfẹ́ mi, òun sì ni ọ̀rẹ́ mi,
1 Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ, ìwọ, arẹwà jùlọ láàrin àwọn obinrin? Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí, kí á lè bá ọ wá a?
2 Olùfẹ́ mi ti lọ sinu ọgbà rẹ̀, níbi ebè igi turari, ó da ẹran rẹ̀ lọ sinu ọgbà, ó lọ já òdòdó lílì.
3 Olùfẹ́ mi ló ni mí, èmi ni mo sì ni olùfẹ́ mi. Láàrin òdòdó lílì, ni ó ti ń da ẹran rẹ̀.
4 Olùfẹ́ mi, o dára bíi Tirisa. O lẹ́wà bíi Jerusalẹmu, O níyì bíi ọ̀wọ́ àwọn ọmọ ogun tí ń gbé ọ̀págun.
5 Yíjú kúrò lọ́dọ̀ mi, nítorí wọn kò jẹ́ kí n gbádùn. Irun orí rẹ dàbí ọ̀wọ́ ewúrẹ́ ninu agbo, tí ń sọ̀kalẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Gileadi.
6 Eyín rẹ dàbí ọ̀wọ́ aguntan, tí wọn ṣẹ̀ṣẹ̀ wẹ̀ tán, gbogbo wọn gún régé, kò sì sí ọ̀kan tí ó yọ ninu wọn,
7 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dàbí ìlàjì èso pomegiranate lábẹ́ ìbòjú rẹ.
8 Àwọn ayaba ìbáà tó ọgọta, kí àwọn obinrin mìíràn sì tó ọgọrin, kí àwọn iranṣẹbinrin sì pọ̀, kí wọn má lóǹkà,
9 sibẹ, ọ̀kan ṣoṣo ni àdàbà mi, olùfẹ́ mi tí ó péye. Ọmọlójú ìyá rẹ̀, ẹni tí kò ní àbààwọ́n lójú ẹni tí ó bí i. Àwọn iranṣẹbinrin ń pe ìyá rẹ̀ ní olóríire. Àwọn ayaba ati àwọn obinrin mìíràn ní ààfin sì ń yìn ín.
10 Ta ni ń yọ bọ̀ bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ yìí, tí ó mọ́ bí ọjọ́, tí ó lẹ́wà bí òṣùpá. Tí ó sì bani lẹ́rù, bí àwọn ọmọ ogun tí wọn dira ogun?
11 Mo lọ sinu ọgbà igi eléso, mo lọ wo ẹ̀ka igi tútù ní àfonífojì, pé bóyá àwọn àjàrà ti rúwé, ati pé bóyá àwọn igi èso pomegiranate tí ń tanná.
12 Kí n tó fura, ìfẹ́ tí ṣe mí bí ẹni tí ó wà ninu ọkọ̀ ogun, tí ara ń wá bíi kí ó bọ́ sójú ogun.
13 Máa pada bọ̀, máa pada bọ̀, ìwọ ọmọbinrin ará Ṣulamu. Máa pada bọ̀, kí á lè máa fi ọ́ ṣe ìran wò. Ẹ óo ṣe máa fi ará Ṣulamu ṣe ìran wò bí ẹni wo ẹni tí ó ń jó níwájú ọ̀wọ́ ọmọ ogun meji?
1 Ẹsẹ̀ rẹ ti dára tó ninu bàtà, ìwọ, ọmọ aládé. Itan rẹ dàbí ohun ọ̀ṣọ́, tí ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà ṣe.
2 Ìdodo rẹ dàbí abọ́, tí kì í gbẹ fún àdàlú waini, ikùn rẹ dàbí òkítì ọkà, tí a fi òdòdó lílì yíká.
3 Ọmú rẹ mejeeji dàbí ọmọ àgbọ̀nrín meji, tí wọn jẹ́ ìbejì.
4 Ọrùn rẹ dàbí ilé-ìṣọ́ tí wọn fi eyín erin kọ́. Ojú rẹ dàbí adágún omi ìlú Heṣiboni, tí ó wà ní ẹnubodè Batirabimu. Imú rẹ dàbí ilé ìṣọ́ Lẹbanoni, tí ó dojú kọ ìlú Damasku.
5 Orí rẹ dàbí adé lára rẹ, ó rí bí òkè Kamẹli, irun rẹ dàbí aṣọ elése-àlùkò tí ó ṣẹ́ léra, wẹ́lẹ́wẹ́lẹ́ irun orí rẹ ń dá ọba lọ́rùn.
6 O dára, o wuni gan-an, olùfẹ́ mi, ẹlẹgẹ́ obinrin.
7 Ìdúró rẹ dàbí igi ọ̀pẹ, ọyàn rẹ ṣù bí ìdì èso àjàrà.
8 Mo ní n óo gun ọ̀pẹ ọ̀hún, kí n di odi rẹ̀ mú. Kí ọmú rẹ dàbí ìdì èso àjàrà, kí èémí ẹnu rẹ rí bí òórùn èso ápù.
9 Ìfẹnukonu rẹ dàbí ọtí waini tí ó dára jùlọ, tí ń yọ́ lọ lọ́nà ọ̀fun, tí ń yọ́ lọ láàrin ètè ati eyín.
10 Olùfẹ́ mi ló ni mí, èmi ni ọkàn rẹ̀ sì fẹ́.
11 Máa bọ̀, olùfẹ́ mi, jẹ́ kí á jáde lọ sinu pápá, kí á lọ sùn ní ìletò kan.
12 Kí á lọ sinu ọgbà àjàrà láàárọ̀ kutukutu, kí á wò ó bóyá àjàrà ti ń rúwé, bóyá ó ti ń tanná; kí á wò ó bóyá igi Pomegiranate ti ń tanná, níbẹ̀ ni n óo ti fi ìfẹ́ mi fún ọ.
13 Èso Mandirake ń tú òórùn dídùn jáde, ẹnu ọ̀nà wa kún fún oríṣìíríṣìí èso tí ó wuni, tí mo ti pèsè wọn dè ọ́, olùfẹ́ mi, ati tuntun ati èyí tó ti pẹ́ nílé.
1 Ìbá wù mí kí o jẹ́ ọmọ ìyá mi ọkunrin, kí ó jẹ́ pé ọmú kan náà ni a jọ mú dàgbà. Bí mo bá pàdé rẹ níta, tí mo fẹnu kò ọ́ lẹ́nu, kì bá tí sí ẹni tí yóo fi mí ṣe yẹ̀yẹ́.
2 Ǹ bá sìn ọ́ wá sílé ìyá mi, ninu ìyẹ̀wù ẹni tí ó tọ́ mi, ǹ bá fún ọ ní waini dídùn mu, àní omi èso Pomegiranate mi.
3 Ọwọ́ òsì rẹ ìbá wà ní ìgbèrí mi, kí o sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ fà mí mọ́ra!
4 Mo kìlọ̀ fun yín, ẹ̀yin obinrin Jerusalẹmu, pé ẹ kò gbọdọ̀ jí olùfẹ́ mi, títí tí yóo fi wù ú láti jí.
5 Ta ní ń bọ̀ láti inú aṣálẹ̀ yìí, tí ó fara ti olùfẹ́ rẹ̀? Lábẹ́ igi èso ápù ni mo ti jí ọ, níbi tí ìyá rẹ ti rọbí rẹ, níbi tí ẹni tí ó bí ọ ti rọbí.
6 Gbé mi lé oókan àyà rẹ bí èdìdì ìfẹ́, bí èdìdì, ní apá rẹ; nítorí ìfẹ́ lágbára bí ikú. Owú jíjẹ burú, àfi bí isà òkú. A máa jó bí iná, bí ọwọ́ iná tí ó lágbára.
7 Ọ̀pọ̀ omi kò lè pa iná ìfẹ́, ìgbì omi kò sì lè tẹ̀ ẹ́ rì. Bí eniyan bá gbìyànjú láti fi gbogbo nǹkan ìní rẹ̀ ra ìfẹ́, ẹ̀tẹ́ ni yóo fi gbà.
8 A ní àbúrò obinrin kékeré kan, tí kò lọ́mú. Kí ni kí á ṣe fún arabinrin wa náà ní ọjọ́ tí wọ́n bá wá tọrọ rẹ̀?
9 Bí ó bá jẹ pé ògiri ni arabinrin wa, à óo mọ ilé-ìṣọ́ fadaka lé e lórí. Bí ó bá jẹ́ pé ìlẹ̀kùn ni, pákó Kedari ni a óo fi yí i ká.
10 Ògiri ni mí, ọmú mi sì dàbí ilé-ìṣọ́; ní ojú olùfẹ́ mi, mo ní alaafia ati ìtẹ́lọ́rùn.
11 Solomoni ní ọgbà àjàrà kan, ní Baali Hamoni. Ó fi ọgbà náà fún àwọn tí wọn yá a, ó ní kí ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn mú ẹgbẹrun (1,000) ìwọ̀n owó fadaka wá, fún èso ọgbà rẹ̀.
12 Èmi ni mo ni ọgbà àjàrà tèmi, ìwọ Solomoni lè ní ẹgbẹrun ìwọ̀n owó fadaka, kí àwọn tí wọn yá ọgbà sì ní igba.
13 Ìwọ tí ò ń gbé inú ọgbà, àwọn ẹlẹgbẹ́ mi ń dẹtí, jẹ́ kí n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ.
14 Yára wá, olùfẹ́ mi, yára bí egbin, tabi ọ̀dọ́ akọ àgbọ̀nrín, sí orí àwọn òkè turari olóòórùn dídùn.