1

1 Ọ̀rọ̀ Jeremaya, ọmọ Hilikaya, ọ̀kan ninu àwọn alufaa tí ó wà ní Anatoti, ní ilẹ̀ Bẹnjamini nìyí.

2 Nígbà ayé Josaya, ọmọ Amoni, ọba Juda, ní ọdún kẹtala tí Josaya gun orí oyè ni OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀.

3 Ó sì tún gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA ní ìgbà ayé Jehoiakimu, ọmọ Josaya, ọba Juda títí di òpin ọdún kọkanla tí Sedekaya ọmọ Josaya jọba ní ilẹ̀ Juda, títí tí ogun fi kó Jerusalẹmu ní oṣù karun-un ọdún náà.

4 OLUWA sọ fún mi pé,

5 “Kí n tó dá ọ sinu ìyá rẹ ni mo ti mọ̀ ọ́, kí wọ́n sì tó bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀, mo yàn ọ́ ní wolii fún àwọn orílẹ̀-èdè.”

6 Mo bá dáhùn pé, “Háà! OLUWA Ọlọrun! Wò ó! N kò mọ ọ̀rọ̀ sọ, nítorí pé ọmọde ni mí.”

7 Ṣugbọn OLUWA dá mi lóhùn, ó ní, “Má pe ara rẹ ní ọmọde, nítorí pé gbogbo ẹni tí mo bá rán ọ sí ni o gbọdọ̀ tọ̀ lọ. Gbogbo ohun tí mo bá pa láṣẹ fún ọ ni o gbọdọ̀ sọ.

8 Má bẹ̀rù wọn, nítorí mo wà pẹlu rẹ, n óo sì gbà ọ́.”

9 OLUWA bá na ọwọ́, ó fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé, “Wò ó, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ọ lẹ́nu.

10 Mo ti fi ọ́ ṣe orí fún àwọn orílẹ̀-èdè ati ìjọba lónìí, láti fà wọ́n tu ati láti bì wọ́n lulẹ̀, láti pa wọ́n run ati láti bì wọ́n ṣubú, láti tún wọn kọ́ ati láti gbé wọn ró.”

11 OLUWA bi mí pé, “Jeremaya, kí ni o rí yìí?” Mo dáhùn, pé, “Ọ̀pá igi Alimọndi ni.”

12 OLUWA bá wí fún mi pé, “Òtítọ́ ni ohun tí o rí, nítorí mò ń sọ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, n óo sì mú un ṣẹ.”

13 OLUWA tún bi mí lẹẹkeji, ó ní, “Kí ni o rí?” Mo bá dáhùn pé, “Mo rí ìkòkò kan tí ó ń hó lórí iná, ó tẹ̀ láti ìhà àríwá sí ìhà gúsù.”

14 OLUWA bá sọ fún mi pé, “Láti ìhà àríwá ni ibi yóo ti dé bá gbogbo àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ náà.

15 Nítorí pé mò ń pe gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní ìjọba àríwá, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀, àwọn ọba wọn yóo sì tẹ́ ìtẹ́ wọn kalẹ̀ ní ẹnubodè Jerusalẹmu, ati yíká odi gbogbo ìlú Juda.

16 N óo dá wọn lẹ́jọ́ nítorí gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe, tí wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀, tí wọn ń sun turari fún àwọn oriṣa, tí wọ́n sì ń bọ ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.

17 Ṣugbọn, ìwọ dìde, di àmùrè rẹ, kí o sì sọ gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ fún wọn. Má jẹ́ kí ẹ̀rù wọn ó bà ọ́, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, n óo dẹ́rù bà ọ́ níwájú wọn.

18 Wò ó, mo ti sọ ọ́ di ìlú tí a mọ odi yíká lónìí, o di òpó irin ati ògiri tí a fi bàbà mọ fún gbogbo ilẹ̀ yìí, ati fún àwọn ọba ilẹ̀ Juda, àwọn ìjòyè, ati àwọn alufaa rẹ̀, ati àwọn eniyan ilẹ̀ náà.

19 Wọn yóo gbógun tì ọ́, ṣugbọn wọn kò ní ṣẹgun rẹ. Nítorí pé mo wà pẹlu rẹ láti gbà ọ́ kalẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

2

1 OLUWA sọ fún mi pé,

2 “Lọ kéde sí etígbọ̀ọ́ àwọn ará Jerusalẹmu, pé èmi OLUWA ní, mo ranti bí o ti fi ara rẹ jì mí nígbà èwe rẹ, ìfẹ́ rẹ dàbí ìfẹ́ iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé; mo ranti bí o ṣe ń tẹ̀lé mi ninu aṣálẹ̀, ní ilẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbin nǹkankan sí.

3 Israẹli jẹ́ mímọ́ fún OLUWA Òun ni àkọ́so èso rẹ̀. Gbogbo àwọn tí wọ́n jẹ ninu àkọ́so èso yìí di ẹlẹ́bi; ibi sì dé bá wọn. Èmi OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.”

4 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ̀yin ilé Jakọbu, ati gbogbo ìdílé Israẹli.

5 OLUWA ní: “Nǹkan burúkú wo ni àwọn baba ńlá yín ní mo fi ṣe àwọn, tí wọ́n jìnnà sí mi; tí wọ́n fi bẹ̀rẹ̀ síí bọ oriṣa lásánlàsàn, tí àwọn pàápàá sì fi di eniyan lásán?

6 Wọn kò bèèrè pé, Níbo ni OLUWA wà, ẹni tí ó kó wa jáde láti ilẹ̀ Ijipti, tí ó sìn wá la aṣálẹ̀ já, ilẹ̀ aṣálẹ̀ tí ó kún fún ọ̀gbun, ilẹ̀ ọ̀dá ati òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ tí eniyan kìí là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kì í gbé?

7 Mo mu yín wá sí ilẹ̀ tí ó lọ́ràá, pé kí ẹ máa gbádùn èso rẹ̀ ati àwọn nǹkan dáradára tí wọ́n wà ninu rẹ̀, ṣugbọn nígbà tí ẹ dé inú rẹ̀, ẹ sọ ilẹ̀ mi di aláìmọ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8 Àwọn alufaa kò bèèrè pé, ‘OLUWA dà?’ Àwọn tí wọn ń ṣe àmójútó òfin kò mọ̀ mí, àwọn olórí ń dìtẹ̀ sí mi, àwọn wolii ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ oriṣa Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn oriṣa lásánlàsàn.

9 “Nítorí náà, mò ń ba yín rojọ́, n óo sì tún bá arọmọdọmọ yín rojọ́ pẹlu.” OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

10 Ó ní, “Ẹ kọjá sí èbúté àwọn ará Kipru kí ẹ wò yíká, tabi kí ẹ ranṣẹ sí Kedari kí ẹ sì ṣe ìwádìí fínnífínní, bóyá irú rẹ̀ ṣẹlẹ̀ rí.

11 Ǹjẹ́ orílẹ̀-èdè kankan tíì pààrọ̀ ọlọrun rẹ̀ rí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe ọlọrun tòótọ́? Ṣugbọn àwọn eniyan mi ti pààrọ̀ ògo wọn, wọ́n ti fi ohun tí kò ní èrè pààrọ̀ rẹ̀.

12 Nítorí náà kí ẹ̀rù kí ó bà ọ́, ìwọ ọ̀run, kí o wárìrì, kí gbogbo nǹkan dàrú mọ́ ọ lójú.”

13 OLUWA wí pé, “Nítorí pé àwọn eniyan mi ṣe nǹkan burúkú meji: wọ́n ti kọ èmi orísun omi ìyè sílẹ̀, wọ́n ṣe kànga fún ara wọn; kànga tí ó ti là, tí kò lè gba omi dúró.

14 “Ṣé ẹrú ni Israẹli ni, àbí ọmọ ẹrú tí ẹrú bí sinu ilé? Báwo ló ṣe wá di ìjẹ fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15 Àwọn kinniun ti bú mọ́ ọn, wọ́n bú ramúramù. Wọ́n sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ahoro. Àwọn ìlú rẹ̀ sì ti tú, wọ́n ti wó palẹ̀, láìsí eniyan tí ń gbé inú wọn.

16 Bákan náà, àwọn ará Memfisi ati Tapanhesi ti fọ́ adé orí rẹ̀.

17 Ṣebí ọwọ́ ara yín ni ẹ fi fà á sí orí ara yín, nígbà tí ẹ̀yin kọ Ọlọrun yín sílẹ̀, nígbà tí ó ń tọ yín sọ́nà?

18 Kí ni èrè tí ẹ rí nígbà tí ẹ lọ sí Ijipti, tí ẹ lọ mu omi odò Naili, àbí kí ni èrè tí ẹ gbà bọ̀ nígbà tí ẹ lọ sí Asiria, tí ẹ lọ mu omi odò Yufurate.

19 Ìwà burúkú yín yóo fìyà jẹ yín, ìpadà sẹ́yìn yín yóo sì kọ yín lọ́gbọ́n. Kí ó da yín lójú pé, nǹkan burúkú ni, ìgbẹ̀yìn rẹ̀ kò sì ní dùn, pé ẹ fi èmi OLUWA Ọlọrun yín sílẹ̀; ìbẹ̀rù mi kò sí ninu yín. Èmi, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

20 OLUWA wí pé, “Nítorí pé ó ti pẹ́ tí ẹ ti bọ́ àjàgà yín, tí ẹ sì ti tú ìdè yín; tí ẹ sọ pé, ẹ kò ní sìn mí. Ẹ̀ ń lọ káàkiri lórí gbogbo òkè, ati lábẹ́ gbogbo igi tútù; ẹ̀ ń foríbalẹ̀, ẹ̀ ń ṣe bíi panṣaga.

21 Sibẹ mo gbìn yín gẹ́gẹ́ bí àjàrà tí mo fẹ́, tí èso rẹ̀ dára. Báwo ni ẹ ṣe wá yipada patapata, tí ẹ di àjàrà igbó tí kò wúlò?

22 Bí ẹ tilẹ̀ fi eérú fọ ara yín, tí ẹ sì fi ọpọlọpọ ọṣẹ wẹ̀, sibẹ, àbààwọ́n ẹ̀bi yín wà níwájú mi.

23 Báwo ní ẹ ṣe lè wí pé ẹ kì í ṣe aláìmọ́; ati pé ẹ kò tẹ̀lé àwọn oriṣa Baali? Ẹ wo irú ìwà tí ẹ hù ninu àfonífojì, kí ẹ ranti gbogbo ibi tí ẹ ṣe bí ọmọ ràkúnmí tí ń lọ, tí ń bọ̀; tí ń tọ ipa ọ̀nà ara rẹ̀.

24 Ẹ dàbíi Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́, tí aṣálẹ̀ ti mọ́ lára, tí ń ṣí imú kiri, nígbà tí ó ń wa akọ tí yóo gùn ún. Ta ló lè dá a dúró? Kí akọ tí ó bá ń wá a má wulẹ̀ ṣe ara rẹ̀ ní wahala, nítorí yóo yọjú nígbà tí àkókò gígùn rẹ̀ bá tó.

25 Má rìn láìwọ bàtà, Israẹli, má sì jẹ́ kí òùngbẹ gbẹ ọ́. Ṣugbọn o sọ pé, ‘Kò sí ìrètí, nítorí àjèjì oriṣa ni mo fẹ́, n óo sì wá wọn kiri.’ ”

26 OLUWA ní, “Bí ojú tíí ti olè nígbà tí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, bẹ́ẹ̀ ni ojú yóo tì yín, ẹ̀yin ọmọ Israẹli. Àtẹ̀yin ati àwọn ọba yín, ati àwọn ìjòyè yín, ati àwọn alufaa yín, ati àwọn wolii yín;

27 ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wí fún igi pé igi ni baba yín, tí ẹ sì ń sọ fún òkúta pé òkúta ni ó bi yín; nítorí pé dípò kí ẹ kọjú sí ọ̀dọ̀ mi, ẹ̀yìn ni ẹ kọ sí mi. Ṣugbọn nígbà tí ìṣòro dé ba yín, ẹ bẹ̀rẹ̀ sí kígbe pè mí pé kí n dìde, kí n gbà yín là.

28 “Ṣugbọn níbo ni àwọn oriṣa yín tí ẹ dá fún ara yín wà? Kí wọn dìde, tí wọ́n bá lè gbà yín ní àkókò ìṣòro yín! Ṣebí bí ìlú yín ti pọ̀ tó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn oriṣa yín náà pọ̀ tó, ẹ̀yin ará Juda.

29 Ẹjọ́ kí ni ẹ wá ń bá mi rò? Ṣebí gbogbo yín ni ẹ̀ ń bá mi ṣọ̀tẹ̀!

30 Mo na àwọn ọmọ yín lásán ni, wọn kò gba ẹ̀kọ́. Ẹ̀yin gan-an ni ẹ fi idà pa àwọn wolii yín ní àparun, bíi kinniun tí ń pa ẹran kiri.

31 Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ gbọ́ ohun tí èmi, OLUWA ń sọ. Ṣé aṣálẹ̀ ni mo jẹ́ fún Israẹli; tabi mo ti di ilẹ̀ òkùnkùn biribiri? Kí ló dé tí ẹ̀yin eniyan mi fí ń sọ pé, ‘A ti di òmìnira, a lè máa káàkiri; a kò ní wá sí ọ̀dọ̀ rẹ mọ́?’

32 Ṣé ọmọbinrin lè gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀? Tabi iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé lè gbàgbé àwọn aṣọ rẹ̀? Sibẹ ẹ ti gbàgbé mi tipẹ́.

33 “Ẹ mọ oríṣìíríṣìí ọ̀nà tí eniyan fi í wá olólùfẹ́ kiri, tóbẹ́ẹ̀ tí ẹ ti fi ìrìnkurìn yín kọ́ àwọn obinrin oníwà burúkú.

34 Ẹ̀jẹ̀ àwọn talaka tí kò ṣẹ̀, wà létí aṣọ yín; bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò bá wọn níbi tí wọ́n ti ń fọ́lé. Gbogbo èyí wà bẹ́ẹ̀,

35 sibẹ ẹ̀ ń sọ pé, ‘Ọwọ́ wa mọ́; dájúdájú, OLUWA ti dá ọwọ́ ibinu rẹ̀ dúró lára wa.’ Ẹ wò ó! N óo dá yín lẹ́jọ́, nítorí ẹ̀ ń sọ pé ẹ kò dẹ́ṣẹ̀.

36 Ẹ̀ ń fi ara yín wọ́lẹ̀ káàkiri; ẹ̀ ń yà síhìn-ín sọ́hùn-ún! Bí Asiria ti dójú tì yín, bẹ́ẹ̀ ni Ijipti náà yóo dójú tì yín.

37 Ẹ óo ká ọwọ́ lérí ni nígbà tí ẹ óo bá jáde níbẹ̀. Nítorí OLUWA ti kọ àwọn tí ẹ gbójúlé, wọn kò sì ní ṣe yín níre.”

3

1 OLUWA ní, “Ṣé bí ọkọ bá kọ iyawo rẹ̀ sílẹ̀, tí iyawo náà sì kó jáde nílé ọkọ, tí ó lọ fẹ́ ẹlòmíràn, ṣé ọkọ rẹ̀ àkọ́kọ́ lè tún lọ gbà á pada? Ṣé ilẹ̀ náà kò ní di ìbàjẹ́? Lẹ́yìn tí ẹ ti ṣe àgbèrè pẹlu ọpọlọpọ olólùfẹ́; ẹ wá fẹ́ pada sọ́dọ̀ mi?

2 Ẹ gbójú sókè kí ẹ wo gbogbo òkè yíká, ibo ni ẹ kò tíì ṣe àgbèrè dé? Ẹ̀ ń dúró de olólùfẹ́ lẹ́bàá ọ̀nà, bí àwọn obinrin Arabia ninu aṣálẹ̀. Ẹ ti fi ìṣekúṣe yín ba ilẹ̀ náà jẹ́.

3 Nítorí náà ni òjò kò ṣe rọ̀, tí òjò àkọ́rọ̀ kò rọ̀ ní àkókò tí ó yẹ. Sibẹsibẹ, ẹ̀ ń gbéjú gbéré bí aṣẹ́wó, ojú kò sì tì yín.

4 Israẹli, o wá ń pè mí nisinsinyii, ò ń sọ pé, ‘Ìwọ ni baba mi, ìwọ ni ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.

5 Ṣé o kò ní dáwọ́ ibinu rẹ dúró ni? Tabi títí ayé ni o óo fi máa bínú?’ Lóòótọ́ o ti sọ bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn o ti ṣe ìwọ̀n ibi tí o lè ṣe.”

6 OLUWA sọ fún mi ní ìgbà ayé ọba Josaya pé: “Ṣé o rí ohun tí Israẹli, alaiṣootọ ẹ̀dá ṣe? Ṣé o rí i bí ó tí ń lọ ṣe àgbèrè lórí gbogbo òkè ati lábẹ́ gbogbo igi tútù?

7 Mo rò pé yóo pada tọ̀ mí wá, lẹ́yìn tí ó bá ṣe àgbèrè rẹ̀ tán ni; ṣugbọn kò pada; Juda arabinrin rẹ̀, alaiṣootọ sì rí i,

8 ó mọ̀ pé nítorí ìwà àgbèrè Israẹli, alaiṣootọ, ni mo ṣe lé e jáde, tí mo sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Sibẹsibẹ Juda tí òun pàápàá jẹ́ alaiṣootọ, kò bẹ̀rù, òun náà lọ ṣe àgbèrè.

9 Nítorí pé ìwà àgbèrè jẹ́ nǹkan kékeré lójú rẹ̀, ó ṣe àgbèrè pẹlu òkúta ati igi ó sì ba ilẹ̀ náà jẹ́.

10 Sibẹsibẹ, lẹ́yìn gbogbo èyí, Juda arabinrin rẹ̀, ọ̀dàlẹ̀, kò fi tọkàntọkàn pada tọ̀ mí wá. Kàkà bẹ́ẹ̀, ojú ayé ni wọ́n ń ṣe. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11 Lẹ́yìn náà OLUWA sọ fún mi pé, “Israẹli jẹ̀bi, aiṣootọ, ṣugbọn kò tíì tó ti Juda, ọ̀dàlẹ̀.

12 Lọ kéde ọ̀rọ̀ yìí sí ìhà àríwá, kí o wí pé: ‘Yipada ìwọ Israẹli alaiṣootọ. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N kò ní bínú sí ọ, nítorí aláàánú ni mí. N kò ní máa bínú lọ títí lae.

13 Ṣá ti gbà pé o jẹ̀bi, ati pé o ti ṣọ̀tẹ̀ sí èmi OLUWA Ọlọrun rẹ. O ti fi ògo rẹ wọ́lẹ̀ fún àwọn àjèjì oriṣa, lábẹ́ gbogbo igi tútù; o kò sì gbọ́ràn sí mi lẹ́nu. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.’

14 “Ẹ yipada, ẹ̀yin alaiṣootọ ọmọ, nítorí èmi ni Oluwa yín. N óo yan ẹnìkọ̀ọ̀kan ninu yín láti inú ìlú kọ̀ọ̀kan, n óo mú meji meji láti inú agbo ilé kọ̀ọ̀kan, n óo sì ko yín wá sí Sioni.

15 N óo fun yín ní àwọn olùṣọ́ aguntan tí ó wù mí, tí yóo fi ìmọ̀ ati òye bọ yín.

16 Nígbà tí ẹ bá pọ̀ síi ní ilẹ̀ náà, ẹ kò ní sọ̀rọ̀ nípa Àpótí Majẹmu OLUWA mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò ní sọ si yín lọ́kàn, ẹ kò ní ranti rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín kò ní fà sí i mọ́, ẹ kò sì ní ṣe òmíràn mọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀

17 Ìtẹ́ OLUWA ni wọ́n óo máa pe Jerusalẹmu nígbà náà. Gbogbo orílẹ̀-èdè yóo parapọ̀ wá sibẹ, níwájú èmi OLUWA, ní Jerusalẹmu, wọn kò ní fi oríkunkun tẹ̀ sí ìmọ̀ burúkú ọkàn wọn mọ́.

18 Nígbà tí àkókò bá tó, àwọn ará ilé Juda yóo tọ àwọn ará ilé Israẹli lọ, wọn yóo sì jọ pada láti ilẹ̀ ìhà àríwá, wọn yóo wá sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín tí wọ́n jogún.”

19 OLUWA ní, “Israẹli, mo fẹ́ fi ọ́ ṣe ọ̀kan ninu àwọn ọmọ mi, tí n óo sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó dára, kí n sì fún ọ ní ogún tí ó dára jù, láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù. Mo sì rò pé o óo máa pè mí ní baba rẹ, ati pé o kò ní pada kúrò lẹ́yìn mi.

20 Dájúdájú bí obinrin alaiṣootọ tíí fi ọkọ rẹ̀ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni o ti ṣe alaiṣootọ sí mi, ìwọ Israẹli. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

21 A gbọ́ ohùn kan lórí àwọn òkè gíga, ẹkún ati ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọkunrin Israẹli ni. Nítorí wọ́n ti yapa kúrò lójú ọ̀nà wọn; wọ́n ti gbàgbé OLUWA Ọlọrun wọn.

22 Ẹ yipada, ẹ̀yin alaiṣootọ ọmọ, n óo mú aiṣootọ yín kúrò. “Wò wá! A wá sọ́dọ̀ rẹ, nítorí ìwọ ni OLUWA Ọlọrun wa.

23 Nítòótọ́, ẹ̀tàn ni àwọn òkè, ati gbogbo ohun tí wọn ń lọ ṣe níbẹ̀; dájúdájú lọ́dọ̀ OLUWA Ọlọrun wa ni ìgbàlà Israẹli wà.

24 Ṣugbọn láti ìgbà èwe wa ni ohun ìtìjú yìí ti pa gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá wa ṣiṣẹ́ fún run: ẹran ọ̀sìn wọn, ati agbo mààlúù wọn, àwọn ọmọ wọn lọkunrin ati lobinrin.

25 Ẹ jẹ́ kí á dojúbolẹ̀ kí ìtìjú wa sì bò wá, nítorí pé a ti ṣẹ̀ sí OLUWA Ọlọrun wa; àtàwa, àtàwọn baba ńlá wa, a kò gbọ́ ti OLUWA Ọlọrun wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní.”

4

1 OLUWA ní, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, bí ẹ bá fẹ́ yipada, ọ̀dọ̀ mi ni kí ẹ pada sí. Mo kórìíra ìbọ̀rìṣà; nítorí náà bí ẹ bá jáwọ́ ninu rẹ̀, tí ẹ kò bá ṣìnà kiri mọ́,

2 tí ẹ bá ń búra pẹlu òtítọ́ pé, ‘Bí OLUWA ti wà láàyè,’ lórí ẹ̀tọ́ ati òdodo, àwọn orílẹ̀-èdè yòókù yóo máa fi orúkọ mi súre fún ara wọn, wọn yóo sì máa ṣògo ninu mi.”

3 Nítorí pé OLUWA sọ fún àwọn ará Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu pé, “Ẹ tún oko yín tí ẹ ti patì tẹ́lẹ̀ kọ, ẹ má sì gbin èso sáàrin ẹ̀gún.

4 Ẹ kọ ara yín ní ilà abẹ́ fún OLUWA, kí ẹ sì kọ ara yín ní ilà ọkàn, ẹ̀yin ará Juda ati ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu; kí ibinu mi má baà dé, bí iná tí ó ń jó tí kò sí ẹni tí ó lè pa á, nítorí iṣẹ́ ibi yín.”

5 Ẹ sọ ọ́ ní Juda, ẹ sì kéde rẹ̀ láàrin Jerusalẹmu pé, “Ẹ fọn fèrè káàkiri ilẹ̀ náà, kí ẹ sì kígbe sókè pé, ‘Ẹ kó ara yín jọ kí á lọ sí àwọn ìlú olódi.’

6 Ẹ gbé àsíá sókè sí Sioni, pé kí wọn sá àsálà, kí wọn má ṣe dúró, nítorí mò ń mú ibi ati ìparun ńlá bọ̀ láti ìhà àríwá.

7 Kinniun kan ti jáde lọ láti inú igbó tí ó wà; ọ̀kan ninu àwọn tí wọ́n máa ń run àwọn orílẹ̀-èdè ti gbéra; ó ti jáde kúrò ní ipò rẹ̀, láti sọ ilẹ̀ yín di ahoro. Yóo pa àwọn ìlú yín run, kò sì ní sí eniyan ninu wọn mọ́.

8 Nítorí èyí, ẹ fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ẹ sọkún kí ẹ máa ké tẹ̀dùntẹ̀dùn, nítorí ìrúnú gbígbóná OLUWA kò tíì yipada kúrò lọ́dọ̀ wa.”

9 OLUWA ní, “Tó bá di ìgbà náà, ojora yóo mú ọba ati àwọn ìjòyè, àwọn alufaa yóo dààmú, ẹnu yóo ya àwọn wolii.”

10 Mo bá dáhùn pé, “Háà, OLUWA Ọlọrun, àṣé ò ń tan àwọn eniyan wọnyi, ati àwọn ará Jerusalẹmu ni, nígbà tí o sọ fún wọn pé, yóo dára fún wọn; àṣé idà ti dé ọrùn wọn!”

11 A óo wí fún àwọn eniyan yìí, ati àwọn ará Jerusalẹmu ní ìgbà náà pé afẹ́fẹ́ gbígbóná kan ń fẹ́ bọ̀ láti orí àwọn òkè, ninu pápá, ó ń fẹ́ bọ̀ sọ́dọ̀ àwọn eniyan mi; kì í ṣe afẹ́fẹ́ lásán tíí fẹ́ pàǹtí ati ìdọ̀tí dànù.

12 Ìjì tí yóo ti ọ̀dọ̀ mi wá yóo le jù bẹ́ẹ̀ lọ. Nisinsinyii èmi ni mò ń fi ọ̀rọ̀ mi dá wọn lẹ́jọ́.

13 Ẹ wò ó! Ó ń bọ̀ bí ìkùukùu, kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ dàbí ìjì. Àwọn ẹṣin rẹ̀ yára ju àṣá lọ. A gbé, nítorí ìparun dé bá wa.

14 Ìwọ Jerusalẹmu, fọ ibi dànù kúrò lọ́kàn rẹ, kí á lè gbà ọ́ là. Yóo ti pẹ́ tó tí èrò burúkú yóo fi máa wà lọ́kàn rẹ?

15 Nítorí a gbọ́ ohùn kan láti ilẹ̀ Dani, tí ń kéde ibi láti òkè Efuraimu.

16 Ẹ kìlọ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè pé ó ń bọ̀, kéde fún Jerusalẹmu pé, àwọn ológun tí ń dó ti ìlú ń bọ̀, láti ilẹ̀ òkèèrè. Wọ́n ń kọ lálá sí àwọn ìlú Juda.

17 Wọ́n yí i ká bí àwọn tí ó ń ṣọ́ oko, nítorí pé ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí OLUWA. OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

18 Ìrìn ẹsẹ̀ rẹ ati ìwà rẹ ni ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi dé bá ọ. Ìjìyà rẹ nìyí, ó sì korò; ó ti dé oókan àyà rẹ.

19 Oró ò! Oró ò! Mò ń jẹ̀rora! Àyà mi ò! Àyà mi ń lù kìkìkì, n kò sì lè dákẹ́; nítorí mo gbọ́ ìró fèrè ogun, ati ariwo ogun.

20 Àjálù ń ṣubú lu àjálù, gbogbo ilẹ̀ ti parun. Lójijì àgọ́ mi wó lulẹ̀, aṣọ títa mi sì fàya ní ìṣẹ́jú kan.

21 Yóo ti pẹ́ tó tí n óo máa wo àsíá ogun, tí n óo sì máa gbọ́ fèrè ogun?

22 OLUWA ní, “Nítorí pé àwọn eniyan mi gọ̀, wọn kò mọ̀ mí. Òmùgọ̀ ọmọ ni wọ́n; wọn kò ní òye. Ọgbọ́n àtiṣe ibi kún inú wọn: ṣugbọn wọn kò mọ rere ṣe.”

23 Mo bojú wo ilé ayé, ilé ayé ṣófo, ó rí júujùu; mo ṣíjú wo ojú ọ̀run, kò sí ìmọ́lẹ̀ níbẹ̀.

24 Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n ń mì tìtì, gbogbo òkè kéékèèké ń sún lọ síhìn-ín sọ́hùn-ún.

25 Mo wò yíká, n kò rí ẹnìkan, gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ti fò sálọ.

26 Mo wò yíká, mo rí i pé gbogbo ilẹ̀ ọlọ́ràá ti di aṣálẹ̀, gbogbo ìlú sì ti di òkítì àlàpà níwájú OLUWA, nítorí ibinu ńlá rẹ̀.

27 Nítorí OLUWA ti sọ pé, gbogbo ilẹ̀ náà yóo di ahoro; sibẹ òpin kò ní tíì dé.

28 Nítorí èyí, ilẹ̀ yóo ṣọ̀fọ̀, ojú ọ̀run yóo sì ṣókùnkùn. Nítorí pé ó ti sọ bẹ́ẹ̀, ó ti rò ó dáradára, kò tíì jáwọ́ ninu rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ní yipada.

29 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin ati ti àwọn tafàtafà, gbogbo ìlú sá jáde fún ààbò. Wọ́n sá wọ inú igbó lọ, wọ́n gun orí òkè lọ sinu pàlàpálá òkúta; gbogbo ìlú sì di ahoro.

30 Ìwọ tí o ti di ahoro, kí ni èrò rẹ tí o fi wọ aṣọ elése àlùkò? Tí o wa nǹkan ọ̀ṣọ́ wúrà sára? Tí o tọ́ ojú? Tí o tọ́ ètè? Asán ni gbogbo ọ̀ṣọ́ tí o ṣe, àwọn olólùfẹ́ rẹ kò kà ọ́ sí, ọ̀nà ati gba ẹ̀mí rẹ ni wọ́n ń wá.

31 Nítorí mo gbọ́ igbe kan, tí ó dàbí igbe obinrin tí ó ń rọbí, ó ń kérora bí aboyún tí ó ń rọbí alákọ̀ọ́bí. Mo gbọ́ igbe Jerusalẹmu tí ń pọ̀ọ̀kà ikú, tí ó na ọwọ́ rẹ̀ síta, tí ń ké pé, “Mo gbé! Mò ń kú lọ, lọ́wọ́ àwọn apànìyàn!”

5

1 Máa sáré lọ, sáré bọ̀ ní àwọn òpópónà Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì ṣàkíyèsí rẹ̀! Wo àwọn gbàgede rẹ̀, bóyá o óo rí ẹnìkan, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó sì ń fẹ́ òtítọ́, tí mo fi lè torí rẹ̀ dáríjì Jerusalẹmu.

2 Lóòótọ́ ni wọ́n ń fi orúkọ mi búra pé, “Bí OLUWA tí ń bẹ,” sibẹ èké ni ìbúra wọn.

3 OLUWA, ṣebí òtítọ́ ni ò ń fẹ́? Ò ń nà wọ́n ní pàṣán, ṣugbọn kò dùn wọ́n, o tẹ̀ wọ́n ní àtẹ̀rẹ́, ṣugbọn wọn kò gbọ́ ìbáwí. Ojú wọn ti dá, ó le koko, wọ́n kọ̀, wọn kò ronupiwada.

4 Nígbà náà ní mo wí lọ́kàn ara mi pé, “Àwọn aláìní nìkan nìwọ̀nyí, wọn kò gbọ́n; nítorí wọn kò mọ ọ̀nà OLUWA, ati òfin Ọlọrun wọn.

5 N óo lọ sọ́dọ̀ àwọn eniyan pataki pataki, n óo sì bá wọn sọ̀rọ̀; nítorí àwọn mọ ọ̀nà OLUWA, ati òfin Ọlọrun wọn.” Ṣugbọn gbogbo wọn náà ni wọ́n ti fa àjàgà wọn dá, tí wọ́n sì ti kọ àṣẹ ati àkóso OLUWA.

6 Nítorí náà, kinniun inú igbó ni yóo wá kì wọ́n mọ́lẹ̀. Ìkookò inú aṣálẹ̀ ni yóo wá jẹ wọ́n run. Àmọ̀tẹ́kùn yóo ba dè wọ́n ní àwọn ìlú wọn, tí ẹnikẹ́ni bá jáde ní ìlú, yóo fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn pọ̀, nígbà pupọ ni wọ́n sì ti yipada kúrò ní ọ̀nà Ọlọrun.

7 OLUWA bi Israẹli pé, “Báwo ni mo ṣe lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ jìn ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ti ń fi àwọn ohun tí kì í ṣe ọlọrun búra. Nígbà tí mo bọ́ wọn ní àbọ́yó tán, wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n dà lọ sí ilé àwọn alágbèrè.

8 Wọ́n dàbí akọ ẹṣin tí a kò tẹ̀ lọ́dàá, tí ó yó, olukuluku wọn ń lé aya aládùúgbò rẹ̀ kiri.

9 Ṣé n kò wá ní jẹ wọ́n níyà fún àwọn nǹkan tí wọ́n ṣe wọnyi? Àbí n kò ní gbẹ̀san ara mi lára irú orílẹ̀-èdè yìí?

10 Kọjá lọ láàrin ọgbà àjàrà rẹ̀ ní poro ní poro, kí o sì pa á run, ṣugbọn má ṣe pa gbogbo rẹ̀ run tán. Gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí pé wọn kì í ṣe ti OLUWA.

11 Nítorí pé ilé Israẹli ati ilé Juda ti ṣe alaiṣootọ sí mi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

12 Àwọn eniyan yìí ti sọ ọ̀rọ̀ èké nípa OLUWA, wọ́n ní, “OLUWA kọ́! Kò ní ṣe nǹkankan; ibi kankan kò ní dé bá wa, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní rí ogun tabi ìyàn.”

13 Àwọn wolii yóo di àgbá òfo; nítorí kò sí ọ̀rọ̀ OLUWA ninu wọn. Bí wọ́n ti wí ni ọ̀rọ̀ yóo rí fún wọn.

14 Nítorí náà, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní, “Nítorí ohun tí wọ́n sọ yìí, wò ó, n óo jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mi di iná lẹ́nu rẹ. N óo sì jẹ́ kí àwọn eniyan wọnyi dàbí igi, iná yóo sì jó wọn run.

15 Ẹ wò ó, ẹ̀yin ọmọ ilé Israẹli, mò ń mú orílẹ̀-èdè kan bọ̀ wá ba yín, láti ilẹ̀ òkèèrè, tí yóo ba yín jà. Láti ayé àtijọ́ ni orílẹ̀-èdè ọ̀hún ti wà, orílẹ̀-èdè alágbára ni. Ẹ kò gbọ́ èdè wọn, ẹ kò sì ní mọ ohun tí wọ́n ń sọ.

16 Apó ọfà wọn dàbí isà òkú tó yanu sílẹ̀, alágbára jagunjagun ni gbogbo wọn.

17 Wọn yóo jẹ yín ní oúnjẹ, wọn yóo sì kó gbogbo ìkórè oko yín lọ, wọn yóo run àwọn ọmọ yín lọkunrin ati lobinrin. Wọn yóo run ẹran ọ̀sìn yín, ati àwọn mààlúù yín. Wọn yóo run èso ọgbà àjàrà yín, ati igi ọ̀pọ̀tọ́ yín. Idà ni wọn yóo fi pa àwọn ìlú olódi yín tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé run.”

18 OLUWA ní, “Ṣugbọn sibẹ, ní gbogbo àkókò yìí, n kò ní pa yín run patapata,

19 nígbà tí àwọn eniyan bá bèèrè pé, ‘Kí ló dé tí OLUWA Ọlọrun wa fi ṣe gbogbo nǹkan wọnyi sí wa?’ Ẹ óo le dá wọn lóhùn pé bí ẹ ṣe kọ èmi OLUWA sílẹ̀, tí ẹ sì ń bọ oriṣa àjèjì ní ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ẹ óo ṣe sin àwọn àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.”

20 OLUWA ní, “Kéde rẹ̀ ní ilẹ̀ Jakọbu, sì ṣe ìfilọ̀ rẹ̀ ní ilẹ̀ Juda:

21 Ẹ wá gbọ́, ẹ̀yin òmùgọ̀, aláìlọ́gbọ́n, ẹ̀yin tí ẹ lójú, ṣugbọn tí ẹ kò ríran; ẹ létí, ṣugbọn tí ẹ kò gbọ́ràn.

22 Ẹ̀rù mi kò tilẹ̀ bà yín? Èmi OLUWA ni mò ń bi yín léèrè. Ẹ wà níwájú mi ẹ kò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀. Èmi tí mo fi iyanrìn pààlà fún omi òkun, tí òkun kò sì gbọdọ̀ rékọjá rẹ̀ títí ayé! Bí ó tilẹ̀ ń ru sókè, kò lágbára kan, kí ìgbì rẹ̀ máa hó yaya, kò lè kọjá ààlà náà.

23 Ṣugbọn ọkàn ẹ̀yin eniyan wọnyi le, ọlọ̀tẹ̀ sì ni yín. Ẹ ti yapa, ẹ sì ti ṣáko lọ.

24 Ẹ kò sì rò ó lọ́kàn yín, kí ẹ wí pé: ‘Ẹ jẹ́ kí á bẹ̀rù OLUWA Ọlọrun wa, tí ó ń fún wa ní òjò lákòókò rẹ̀, ati òjò àkọ́rọ̀ ati àrọ̀kẹ́yìn; OLUWA tí ó ń bá wa mú ọjọ́ ìkórè lọ́wọ́, tí kì í jẹ́ kí àsìkò ìkórè ó yẹ̀.’

25 Àìdára yín ti yí ìgbà wọnyi pada, ẹ̀ṣẹ̀ yín ti dínà ohun rere fun yín.

26 “Àwọn eniyan burúkú wà láàrin àwọn eniyan mi, wọ́n ń dọdẹ eniyan bí ẹni dọdẹ ẹyẹ, wọ́n dẹ tàkúté, wọ́n fi ń mú eniyan.

27 Ilé wọn kún fún ìwà ọ̀dàlẹ̀, bíi kùùkú tí ó kún fún ẹyẹ. Nítorí èyí, wọ́n di eniyan ńlá, wọ́n di olówó,

28 wọ́n sanra, ara wọn sì ń dán. Ṣugbọn iṣẹ́ ibi wọn kò ní ààlà. Wọn kìí dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ fún aláìníbaba, kí ó lè rí ẹ̀tọ́ rẹ̀ gbà; wọn kò sì jẹ́ gbèjà aláìní, kí wọ́n bá a dáàbò bo ẹ̀tọ́ rẹ̀ nílé ẹjọ́.

29 Ṣé n kò wá ní jẹ wọ́n níyà fún àwọn nǹkan tí wọ́n ṣe wọnyi? Kí n má gbẹ̀san ara mi, lára irú orílẹ̀-èdè yìí?

30 Nǹkan burúkú tó yani lẹ́nu, ní ń ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà:

31 Àwọn wolii ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn alufaa ń sọ ọ̀rọ̀ èké àwọn wolii di òfin, àwọn eniyan mi sì fẹ́ ẹ bẹ́ẹ̀. Ṣugbọn kí ni wọ́n óo ṣe nígbà tí òpin bá dé?”

6

1 Ẹ̀yin ọmọ Bẹnjamini, ẹ sá àsálà! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ogun ní Tekoa, kí ẹ ṣe ìkìlọ̀ fún wọn ní Beti Hakikeremu, nítorí pé nǹkan burúkú ati ìparun ńlá ń bọ̀ láti ìhà àríwá.

2 Jerusalẹmu, Ìlú Sioni dára, ó sì lẹ́wà, ṣugbọn n óo pa á run.

3 Àwọn ọba ati àwọn ọmọ ogun wọn yóo kọlù ú, wọn yóo pa àgọ́ yí i ká, ẹgbẹ́ ọmọ ogun kọ̀ọ̀kan yóo pàgọ́ sí ibi tí ó wù ú.

4 Wọn yóo sì wí pé, “Ẹ múra kí á bá a jagun; ẹ dìde kí á lè kọlù ú lọ́sàn-án gangan!” Wọn óo tún sọ pé, “A gbé! Nítorí pé ọjọ́ ti lọ, ilẹ̀ sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣú!

5 Ẹ dìde kí á lè kọlù ú, lóru; kí á wó àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀!”

6 Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun ti pàṣẹ fún àwọn ọ̀tá pé: “Ẹ gé àwọn igi tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀; kí ẹ fi mọ òkítì kí ẹ sì dótì í. Dandan ni kí n fi ìyà jẹ ìlú náà, nítorí kìkì ìwà ìninilára ló kún inú rẹ̀.

7 Bí omi ṣé ń sun jáde ninu kànga, bẹ́ẹ̀ ni ibi ń sun ní Jerusalẹmu. Ìròyìn ìwà ipá ati ti jàgídíjàgan ń kọlura wọn ninu rẹ̀, àìsàn ati ìpalára ni à ń rí níbẹ̀ nígbà gbogbo.

8 Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu! Ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ tí mò ń ṣe fun yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi pẹlu yín óo pínyà, n óo sì sọ Jerusalẹmu di ahoro, ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé ibẹ̀ mọ́.”

9 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní: “Ẹ ṣa àwọn ọmọ Israẹli yòókù jọ, bí ìgbà tí eniyan bá ń ṣa èso àjàrà tókù lẹ́yìn ìkórè. Tún dá ọwọ́ pada sẹ́yìn, kí o fi wọ́ ara àwọn ẹ̀ka, bí ẹni tí ń ká èso àjàrà.”

10 Mo ní, “Ta ni kí n bá sọ̀rọ̀, tí yóo gbọ́? Ta ni kí n kìlọ̀ fún tí yóo gbà? Etí wọn ti di, wọn kò lè gbọ́ràn mọ́. Ọ̀rọ̀ OLUWA ń rùn létí wọn, wọn kò fẹ́ gbọ́ mọ́.

11 Ibinu ìwọ OLUWA mú kí inú mi máa ru, ara mi kò sì gbà á mọ́.” OLUWA bá sọ fún mi pé, “Tú ibinu mi dà sórí àwọn ọmọde ní ìta gbangba, ati àwọn ọdọmọkunrin níbi tí wọ́n péjọ sí. Ogun yóo kó wọn, tọkọtaya, àtàwọn àgbàlagbà àtàwọn arúgbó kùjọ́kùjọ́.

12 Ilé wọn yóo di ilé onílé, oko wọn, ati àwọn aya wọn pẹlu, yóo di ti ẹni ẹlẹ́ni. Nítorí pé n óo na ọwọ́ ibinu mi sí àwọn tí ń gbé ilẹ̀ náà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

13 OLUWA ní, “Láti orí àwọn mẹ̀kúnnù títí dé orí àwọn eniyan pataki pataki, gbogbo wọn ni wọ́n fẹ́ràn èrè àjẹjù; láti orí àwọn wolii títí dé orí àwọn alufaa, èké ni gbogbo wọn.

14 Wọn kò wẹ egbò àwọn eniyan mi jiná, wọ́n ń kígbe pé: ‘Alaafia ni, alaafia ni’, nígbà tí kò sí alaafia.

15 Ǹjẹ́ ojú a tilẹ̀ máa tì wọ́n nígbà tí wọ́n bá ń hu ìwà ìbàjẹ́? Rárá o, ojú kì í tì wọ́n; nítorí pé wọn kò lójútì. Nítorí náà, àwọn náà óo ṣubú nígbà tí àwọn yòókù bá ṣubú, a ó bì wọ́n ṣubú nígbà tí mo bá ń jẹ wọ́n níyà, Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

16 OLUWA ní, “Ẹ lọ dúró ní oríta kí ẹ wo òréré, ẹ bèèrè àwọn ọ̀nà àtijọ́, níbi tí ọ̀nà dáradára wà, kí ẹ sì máa tọ̀ ọ́. Kí ẹ lè ní ìsinmi.” Ṣugbọn wọ́n kọ̀, wọ́n ní, “A kò ní tọ ọ̀nà náà.”

17 Mo fi àwọn aṣọ́nà ṣọ́nà nítorí yín. Mo wí fún wọn pé, “Ẹ máa dẹtí sílẹ̀ sí fèrè ogun!” Ṣugbọn wọ́n ní, “A kò ní dẹtí sílẹ̀.”

18 OLUWA ní, “Nítorí náà, ẹ gbọ́, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí ẹ̀yin eniyan sì mọ ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí wọn.

19 Gbọ́! Ìwọ ilẹ̀; n óo fa ibi lé àwọn eniyan wọnyi lórí, wọn óo jèrè èso ìwà burúkú wọn; nítorí pé wọn kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti tàpá sí òfin mi.

20 Kí ni anfaani turari, tí wọn mú wá fún mi láti Ṣeba, tabi ti ọ̀pá turari olóòórùn dídùn tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè wá? N kò tẹ́wọ́ gba ọrẹ ẹbọ sísun tí ẹ mú wá siwaju mi, bẹ́ẹ̀ ni ẹbọ yín kò dùn mọ́ mi.

21 Nítorí náà, n óo gbé ohun ìdínà sọ́nà fún àwọn eniyan wọnyi, wọn óo sì fẹsẹ̀ kọ; ati baba, àtọmọ wọn, àtaládùúgbò, àtọ̀rẹ́, gbogbo wọn ni yóo parun.”

22 OLUWA ní, “Wò ó, àwọn eniyan kan ń bọ̀ láti ilẹ̀ àríwá, orílẹ̀-èdè ńlá ń gbéra bọ̀ láti òpin ayé.

23 Wọ́n ń kó ọrun ati ọ̀kọ̀ bọ̀, ìkà ni wọ́n, wọn kò sì lójú àánú. Ìró wọn dàbí híhó omi òkun, bí wọ́n ti ń gun ẹṣin bọ̀. Wọ́n tò bí àwọn tí ń lọ sójú ogun, wọ́n dótì ọ́, ìwọ Jerusalẹmu!”

24 A gbúròó wọn, ọwọ́ wa rọ; ìdààmú dé bá wa, bí ìrora obinrin tí ó ń rọbí.

25 Ẹ má lọ sinu oko, ẹ má sì ṣe rìn lójú ọ̀nà náà, nítorí ọ̀tá mú idà lọ́wọ́, ìdágìrì sì wà káàkiri.

26 Ẹ̀yin eniyan mi, ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ máa yí ninu eérú; ẹ máa ṣọ̀fọ̀, bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ kanṣoṣo; kí ẹ sì máa sunkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóo bò yín.

27 Mo ti fi ọ́ ṣe ẹni tí yóo máa dán àwọn eniyan mi wò, o óo máa dán wọn wò bí ẹni dán irin wò, o óo gbìyànjú láti mọ ọ̀nà wọn, kí o lè yẹ ọ̀nà wọn wò, kí o sì mọ̀ ọ́n.

28 Ọlọ̀tẹ̀, aláìgbọràn ni gbogbo wọn, wọn á máa sọ̀rọ̀ eniyan lẹ́yìn. Wọ́n dàbí idẹ àdàlú mọ́ irin, àmúlùmálà ni gbogbo wọn.

29 Lóòótọ́ à ń fi ẹwìrì fẹ́ iná, òjé sì ń yọ́ lórí iná; ṣugbọn alágbẹ̀dẹ ń yọ́ irin lásán ni, kò mú ìbàjẹ́ ara rẹ̀ kúrò.

30 Ìdọ̀tí fadaka tí a kọ̀ tì ni wọ́n, nítorí pé OLUWA ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.

7

1 OLUWA rán Jeremaya níṣẹ́, ó ní

2 kí Jeremaya dúró sí ẹnu ọ̀nà ilé OLUWA, kí ó sì kéde pé: “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ẹnu ọ̀nà wọnyi wọlé láti sin OLUWA.

3 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní: ‘Ẹ tún ìrìn ẹsẹ̀ yín ati iṣẹ́ ọwọ́ yín ṣe, kí n lè jẹ́ kí ẹ máa gbé ìhín.

4 Ẹ má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn yìí pé: “Tẹmpili OLUWA nìyí, kò séwu, tẹmpili OLUWA nìyí.”

5 “ ‘Bí ẹ bá tún ìrìn ẹsẹ̀ yín ati iṣẹ́ ọwọ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ bá ń dá ẹjọ́ òtítọ́,

6 tí ẹ kò bá fi ìyà jẹ àwọn àlejò, ati àwọn aláìníbaba, tabi àwọn opó, tabi kí ẹ máa ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, tí ẹ kò sì máa bọ oriṣa káàkiri, kí ẹ fi kó bá ara yín,

7 n óo jẹ́ kí ẹ máa gbé ibí yìí títí lae, lórí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín láti ìgbà laelae.

8 “ ‘Ẹ wò ó! Ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò lè mú èrè wá ni ẹ gbójú lé.

9 Ṣé ẹ fẹ́ máa jalè, kí ẹ máa pa eniyan, kí ẹ máa ṣe àgbèrè, kí ẹ máa búra èké, kí ẹ máa sun turari sí oriṣa Baali, kí ẹ máa bọ àwọn oriṣa tí ẹ kò mọ̀ káàkiri;

10 kí ẹ sì tún máa wá jọ́sìn níwájú mi ninu ilé yìí, ilé tí à ń fi orúkọ mi pè; kí ẹ máa wí pé, “OLUWA ti gbà wá là;” kí ẹ sì tún pada lọ máa ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí ẹ tí ń ṣe?

11 Ṣé lójú tiyín, ilé yìí, tí à ń fi orúkọ mi pè, ó ti wá di ibi ìsápamọ́ sí fún àwọn olè? Mo ti ri yín; èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

12 Nisinsinyii, ẹ lọ sí ilé mi ní Ṣilo, níbi ìjọ́sìn mi àkọ́kọ́, kí ẹ sì wo ohun tí mo ṣe sí i, nítorí ìwà burúkú Israẹli, àwọn eniyan mi.

13 Nisinsinyii, nítorí gbogbo ohun tí ẹ̀ ń ṣe wọnyi, tí mo sì ń ba yín sọ̀rọ̀ lemọ́lemọ́, tí ẹ kò gbọ́, tí mo pè yín, tí ẹ kò dáhùn,

14 bí mo ti ṣe sí Ṣilo ni n óo ṣe ilé tí à ń fi orúkọ mi pè, tí ẹ gbójú lé; ati ilẹ̀ tí mo fún ẹ̀yin ati àwọn baba ńlá yín. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

15 N óo le yín kúrò níwájú mi, bí mo ti lé àwọn ọmọ Efuraimu, tí wọ́n jẹ́ arakunrin yín dànù.’ ”

16 OLUWA ní, “Ìwọ Jeremaya ní tìrẹ, má bẹ̀bẹ̀ fún àwọn eniyan wọnyi, má sọkún nítorí wọn, tabi kí o gbadura fún wọn. Má sì bẹ̀ mí nítorí wọn, nítorí n kò ní gbọ́.

17 Ṣé o kò rí àwọn ohun tí wọn ń ṣe ninu àwọn ìlú Juda ati ní ìgboro Jerusalẹmu ni?

18 Àwọn ọmọ ń kó igi jọ, àwọn baba wọn ń dá iná, àwọn obinrin ń po ìyẹ̀fun láti fi ṣe àkàrà fún Ayaba Ọ̀run. Wọ́n sì ń ta ọtí sílẹ̀ fún àwọn oriṣa láti mú mi bínú.

19 Ṣé èmi ni wọ́n ń mú bínú? Kì í ṣe pé ara wọn ni wọ́n ń ṣe, tí wọ́n sì ń dójú ti ara wọn?

20 Nítorí náà, èmi OLUWA Ọlọrun óo tú ibinu gbígbóná mi sórí ibí yìí, n óo bínú sí eniyan ati ẹranko, ati igi oko ati èso ilẹ̀. Ibinu mi óo jó wọn run bí iná, kò sì ní ṣe é pa.

21 “Ẹ da ẹbọ sísun yín pọ̀ mọ́ ẹran tí ẹ fi rúbọ, kí ẹ lè rí ẹran jẹ; Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

22 Nítorí ní ọjọ́ tí mo kó àwọn baba yín jáde ní ilẹ̀ Ijipti, n kò bá wọn sọ̀rọ̀ ẹbọ sísun tabi ẹbọ rírú, bẹ́ẹ̀ ni n kò pàṣẹ rẹ̀ fún wọn.

23 Àṣẹ tí mo pa fún wọn ni pé kí wọn gbọ́ràn sí mi lẹ́nu. Mo ní n óo máa jẹ́ Ọlọrun wọn, àwọn náà óo sì máa jẹ́ eniyan mi; mo ní kí wọn máa tọ ọ̀nà tí mo bá pa láṣẹ fún wọn, kí ó lè dára fún wọn.

24 Ṣugbọn wọn kò gbọ́ràn, wọn kò sì tẹ́tí sí mi. Wọ́n ń tẹ̀lé ìmọ̀ ara wọn, wọ́n ń ṣe oríkunkun, dípò kí wọ́n máa lọ siwaju, ẹ̀yìn ni wọ́n ń pada sí.

25 Láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní ilẹ̀ Ijipti títí di òní, lojoojumọ ni mò ń rán àwọn wolii iranṣẹ mi sí wọn léraléra.

26 Sibẹ wọn kò gbọ́ tèmi, wọn kò tẹ́tí sí mi. Kàkà bẹ́ẹ̀, oríkunkun ni wọ́n ń ṣe. Iṣẹ́ burúkú wọn ju ti àwọn baba ńlá wọn lọ.

27 “Gbogbo ọ̀rọ̀ wọnyi ni o óo sọ fún wọn, ṣugbọn wọn kò ní gbọ́. O óo pè wọ́n, ṣugbọn wọn kò ní dá ọ lóhùn.

28 O óo sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ohùn OLUWA Ọlọrun rẹ̀, tí kò sì gbọ́ ìbáwí. Òtítọ́ kò sí mọ́ ninu ìṣe yín, bẹ́ẹ̀ ni, kò sì sí ninu ọ̀rọ̀ ẹnu yín.’

29 “Ẹ gé irun orí yín dànù, ẹ lọ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn lórí òkè, nítorí OLUWA ti kọ ìran yín sílẹ̀, ó ti fi ibinu ta ìran yín nù.

30 “Àwọn ọmọ Juda ti ṣe nǹkan burúkú. Wọ́n gbé ère wọn kalẹ̀ ninu ilé tí à ń fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ti sọ ọ́ di aláìmọ́.

31 Wọ́n kọ́ pẹpẹ Tofeti ní àfonífojì Hinomu, wọ́n ń sun àwọn ọmọkunrin ati àwọn ọmọbinrin wọn níná níbẹ̀. N kò pa irú àṣẹ bẹ́ẹ̀ fún wọn; irú nǹkan bẹ́ẹ̀ kò tilẹ̀ fi ìgbà kan sí lọ́kàn mi.

32 Nítorí náà nígbà tó bá yá, a kò ní pè é ní Tofeti tabi àfonífojì ọmọ Hinomu mọ́, àfonífojì ìpànìyàn ni a óo sì máa pè é. Tofeti ni wọn yóo sì máa sin òkú sí nígbà tí kò bá sí ààyè ní ibòmíràn mọ́.

33 Òkú àwọn eniyan yìí yóo di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ati fún àwọn ẹranko, kò sì ní sí ẹni tí yóo lé wọn.

34 N óo fi òpin sí ẹ̀rín ati ìró ayọ̀ ní Jerusalẹmu, a kò sì ní gbọ́ ohùn ọkọ iyawo ati ohùn iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé níbẹ̀ mọ́; nítorí pé n óo sọ ilẹ̀ náà di ahoro.

8

1 “Tó bá di ìgbà náà, wọn yóo kó egungun àwọn ọba Juda jáde kúrò ninu ibojì wọn, ati egungun àwọn ìjòyè ibẹ̀; ati ti àwọn alufaa, ati ti àwọn wolii, ati ti àwọn ará Jerusalẹmu.

2 Wọn óo fọ́n wọn dà sílẹ̀ ninu oòrùn, ati lábẹ́ òṣùpá ati àwọn ìràwọ̀ tí wọ́n ní ìfẹ́ sí, tí wọ́n sì sìn; àwọn ohun tí wọn ń wá kiri, tí wọn ń ṣe ìwádìí lọ́dọ̀ wọn, tí wọ́n sì ń bọ. A kò ní kó egungun wọn jọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní sin wọ́n. Wọn óo dàbí ìgbọ̀nsẹ̀ lórí ilẹ̀.

3 Yóo sàn kí àwọn tí ó bá kù ninu ìran burúkú yìí kú ju kí wọ́n wà láàyè lọ, ní ibikíbi tí mo bá lé wọn lọ. Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

4 OLUWA ní kí n sọ fún wọn pé, “Ṣé bí eniyan bá ṣubú kì í tún dìde mọ́? Àbí bí eniyan bá ṣìnà, kì í pada mọ́?

5 Kí ló dé tí àwọn eniyan wọnyi fi yipada kúrò lọ́dọ̀ mi, tí wọn ń lọ láì bojúwẹ̀yìn? Ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ni wọ́n sì wawọ́ mọ́; wọ́n kọ̀, wọn kò pada sọ́dọ̀ mi.

6 Mo tẹ́tí sílẹ̀ kí n gbọ́ tiwọn, ṣugbọn wọn kò sọ̀rọ̀ rere. Kò sí ẹni tí ó kẹ́dùn iṣẹ́ ibi rẹ̀, kí ó wí pé, ‘Kí ni mo ṣe yìí?’ Olukuluku tẹ̀ sí ọ̀nà tí ó wù ú, bí ẹṣin tí ń sáré lọ ojú ogun.

7 Ẹyẹ àkọ̀ tí ń fò lójú ọ̀run pàápàá mọ àkókò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ sì ni àdàbà, ati lékèélékèé, ati alápàáǹdẹ̀dẹ̀; wọ́n mọ àkókò tí ó yẹ láti ṣípò pada. Ṣugbọn àwọn eniyan mi kò mọ òfin OLUWA.

8 Báwo ni ẹ ṣe lè wí pé, ‘Ọlọ́gbọ́n ni wá, a sì mọ òfin OLUWA?’ Ṣugbọn àwọn akọ̀wé ti fi gègé irọ́ wọn sọ ọ́ di èké.

9 Ojú yóo ti àwọn ọlọ́gbọ́n: ìdààmú yóo bá wọn, ọwọ́ yóo sì tẹ̀ wọ́n. Wò ó! Wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ OLUWA sílẹ̀, ọgbọ́n wo ni ó kù tí wọ́n gbọ́n?

10 Nítorí náà, n óo fi aya wọn fún ẹlòmíràn, n óo fi oko wọn fún àwọn tí yóo ṣẹgun wọn. Nítorí pé láti orí àwọn mẹ̀kúnnù, títí dé orí àwọn eniyan pataki pataki, gbogbo wọn ni wọ́n ń lépa èrè àjẹjù. Láti orí wolii títí kan alufaa, èké ni gbogbo wọn.

11 Wọn kò wẹ egbò àwọn eniyan mi jinná, wọ́n ń kígbe pé, ‘Alaafia ni, alaafia ni,’ bẹ́ẹ̀ sì ni kò sí alaafia.

12 Ǹjẹ́ ojú a tilẹ̀ máa tì wọ́n nígbà tí wọ́n bá ń hu ìwà ìbàjẹ́? Rárá o, ojú kì í tì wọ́n, nítorí pé wọn kò lójútì. Nítorí náà àwọn náà óo ṣubú nígbà tí àwọn yòókù bá ṣubú, a óo bì wọ́n ṣubú nígbà tí mo bá ń jẹ wọ́n níyà, OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

13 “Ní àkókò ìkórè, kò ní sí èso lórí àjàrà, igi ọ̀pọ̀tọ́ kò ní ní èso lórí, àwọn ewé pàápàá yóo gbẹ, ohun tí mo fún wọn yóo di ti ẹlòmíràn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

14 Àwọn eniyan Ọlọrun bá dáhùn pé, “Kí ló dé tí a fi jókòó jẹ̀kẹ̀tẹ̀? Ẹ jẹ́ kí á kó ara wa jọ, kí á sá lọ sí àwọn ìlú olódi, kí á sì parun sibẹ; nítorí OLUWA Ọlọrun wa ti fi wá lé ìparun lọ́wọ́, ó ti fún wa ní omi tí ó ní májèlé mu, nítorí pé a ti ṣẹ̀ ẹ́.

15 À ń retí alaafia, ṣugbọn ire kankan kò dé. Àkókò ìwòsàn ni à ń retí, ṣugbọn ìpayà ni a rí.

16 Ẹ gbọ́ bí ẹṣin wọn tí ń fọn imú, ní ilẹ̀ Dani; gbogbo ilẹ̀ ń mì tìtì nítorí ìró yíyan ẹṣin wọn. Wọ́n wá run ilẹ̀ náà, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀, ati ìlú ati àwọn tí wọn ń gbé inú rẹ̀.”

17 OLUWA ní, “Wò ó! N óo rán ejò sí ààrin yín: paramọ́lẹ̀ tí kò ní gbóògùn; wọn yóo sì bù yín jẹ.”

18 Ìbànújẹ́ mi pọ̀ kọjá ohun tí ó ṣe é wòsàn, àárẹ̀ mú ọkàn mi.

19 Ẹ gbọ́ igbe àwọn eniyan mi jákèjádò ilẹ̀ náà tí wọn ń bèèrè pé, “Ṣé OLUWA kò sí ní Sioni ni? Tabi ọba rẹ̀ kò sí ninu rẹ̀ ni?” OLUWA, ọba wọn dáhùn pé, “Kí ló dé tí wọn ń fi ère wọn mú mi bínú, pẹlu àwọn oriṣa ilẹ̀ àjèjì tí wọn ń bọ?”

20 Àwọn eniyan ní, “Ìkórè ti parí, àsìkò ẹ̀ẹ̀rùn ti kọjá, sibẹ a kò rí ìgbàlà.”

21 Nítorí ọgbẹ́ àwọn eniyan mi ni ọkàn mi ṣe gbọgbẹ́. Mò ń ṣọ̀fọ̀, ìdààmú sì bá mi.

22 Ṣé kò sí ìwọ̀ra ní Gileadi ni? Àbí kò sí oníwòsàn níbẹ̀? Kí ló dé tí àìsàn àwọn eniyan mi kò sàn?

9

1 Orí mi ìbá jẹ́ kìkì omi, kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé; tọ̀sán-tòru ni ǹ bá fi máa sọkún, nítorí àwọn eniyan mi tí ogun ti pa.

2 Ìbá ṣe pé mo ní ilé èrò kan ninu aṣálẹ̀, ǹ bá kó àwọn eniyan mi dà sílẹ̀ níbẹ̀, ǹ bá sì kúrò lọ́dọ̀ wọn; nítorí alágbèrè ni gbogbo wọn, ati àgbájọ àwọn alárèékérekè eniyan.

3 Bí ẹni kẹ́ ọrun ni wọ́n kẹ́ ahọ́n wọn, láti máa fọ́n irọ́ jáde bí ẹni ta ọfà; dípò òtítọ́ irọ́ ní ń gbilẹ̀ ní ilẹ̀ náà. OLUWA ní, “Wọ́n ń tinú ibi bọ́ sinu ibi, wọn kò sì mọ̀ èmi OLUWA.”

4 Kí olukuluku ṣọ́ra lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, kí ó má sì gbẹ́kẹ̀lé arakunrin rẹ̀ kankan. Nítorí pé ajinnilẹ́sẹ̀ ni gbogbo arakunrin, a-fọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-ba-tẹni-jẹ́ sì ni gbogbo aládùúgbò.

5 Olukuluku ń tan ọ̀rẹ́ rẹ̀ jẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ń sọ òtítọ́. Wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn ní irọ́ pípa; wọ́n dẹ́ṣẹ̀ títí, ó sú wọn, wọn kò sì ronú àtipàwàdà.

6 Ìninilára ń gorí ìninilára, ẹ̀tàn ń gorí ẹ̀tàn, OLUWA ní, “Wọ́n kọ̀ wọn kò mọ̀ mí.”

7 Nítorí náà, ó ní: “Wò ó! N óo fọ̀ wọ́n mọ́, n óo dán wọn wò. Àbí, kí ni kí n tún ṣe fún àwọn eniyan yìí?

8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà apanirun, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn. Olukuluku ń sọ̀rọ̀ alaafia jáde lẹ́nu fún aládùúgbò rẹ̀, ṣugbọn ète ikú ni ó ń pa sí i ninu ọkàn rẹ̀.

9 Ṣé n kò wá ní jẹ wọ́n níyà fún àwọn nǹkan tí wọ́n ṣe wọnyi? Àbí n kò ní gbẹ̀san ara mi lára irú orílẹ̀-èdè yìí?”

10 Mo ní, “Gbé ẹnu sókè kí o sọkún nítorí àwọn òkè ńlá, sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn nítorí àwọn pápá inú aṣálẹ̀, nítorí gbogbo wọn ti di ahoro, láìsí ẹnìkan tí yóo la ààrin wọn kọjá. A kò ní gbọ́ ohùn ẹran ọ̀sìn níbẹ̀. Ati ẹyẹ, ati ẹranko, gbogbo wọn ti sá lọ.”

11 OLUWA ní, “N óo sọ Jerusalẹmu di àlàpà ati ibùgbé ajáko. N óo sọ àwọn ìlú Juda di ahoro ẹnikẹ́ni kò ní gbé inú wọn mọ́. Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

12 Mo bá bèèrè pé, “Ta ni ẹni tí ó gbọ́n, tí òye nǹkan yìí yé? Ta ni OLUWA ti bá sọ̀rọ̀, kí ó kéde rẹ̀? Kí ló dé tí ilẹ̀ náà fi parun, tí ó sì dàbí aṣálẹ̀ tóbẹ́ẹ̀, tí ẹnikẹ́ni kò fi gba ibẹ̀ kọjá?”

13 OLUWA bá dáhùn, ó ní, “Nítorí pé wọ́n kọ òfin tí mo gbékalẹ̀ fún wọn sílẹ̀, wọn kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ mi,

14 ṣugbọn wọ́n ń fi agídí ṣe ìfẹ́ ọkàn wọn, wọ́n ń bọ àwọn oriṣa Baali, bí àwọn baba wọn ti kọ́ wọn.

15 Nítorí náà, n óo fún wọn ní igi tí ó korò jẹ, n óo sì fún wọn ní omi tí ó ní májèlé mu. Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

16 N óo fọ́n wọn ká sí ààrin àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn ati àwọn baba ńlá wọn kò mọ̀, n óo sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá yọ idà tẹ̀lé wọn títí tí n óo fi pa wọ́n run.”

17 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní: “Ẹ ronú sí ọ̀rọ̀ yìí kí ẹ pe àwọn obinrin tíí máa ń ṣọ̀fọ̀ wá, ẹ ranṣẹ pe àwọn obinrin tí wọ́n mọ ẹkún sun dáradára;

18 kí wọ́n wá kíá, kí wọ́n wá máa sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn lé wa lórí, kí omi sì máa dà lójú wa pòròpòrò.

19 Nítorí a gbọ́ tí ẹkún sọ ní Sioni, wọ́n ń ké pé, ‘A gbé! Ìtìjú ńlá dé bá wa, a níláti kó jáde nílé, nítorí pé àwọn ọ̀tá ti wó ilé wa.’ ”

20 Mo ní, “Ẹ̀yin obinrin, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀. Ẹ kọ́ àwọn ọmọ yín obinrin ní ẹkún sísun, kí ẹ sì kọ́ aládùúgbò yín ní orin arò.

21 Nítorí ikú ti dé ojú fèrèsé wa, ó ti wọ ààfin wa. Ikú ń pa àwọn ọmọde nígboro, ati àwọn ọdọmọkunrin ní gbàgede.”

22 Sọ wí pé, “Òkú eniyan yóo sùn lọ nílẹ̀ bí ìgbọ̀nsẹ̀ lórí pápá tí ó tẹ́jú, ati bíi ìtí ọkà lẹ́yìn àwọn tí wọn ń kórè ọkà, kò sì ní sí ẹni tí yóo kó wọn jọ. OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.”

23 OLUWA ní, “Kí ọlọ́gbọ́n má fọ́nnu nítorí ọgbọ́n rẹ̀, kí alágbára má fọ́nnu nítorí agbára rẹ̀; kí ọlọ́rọ̀ má sì fọ́nnu nítorí ọrọ̀ rẹ̀.

24 Ṣugbọn ẹni tí ó bá fẹ́ fọ́nnu, ohun tí ó lè máa fi fọ́nnu ni pé òun ní òye ati pé òun mọ̀ pé, èmi OLUWA ni OLUWA tí ń ṣe ẹ̀tọ́, tí sì ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òdodo hàn lórí ilẹ̀ ayé; nítorí pé àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ ni mo ní inú dídùn sí.”

25 Ó ní, “Ọjọ́ ń bọ̀, tí n óo fìyà jẹ àwọn tí a kọ nílà, ṣugbọn tí wọn ń ṣe bí aláìkọlà,

26 àwọn ará Ijipti, àwọn ọmọ Juda, àwọn ará Edomu, ati àwọn ọmọ Amoni àwọn ará Moabu, ati gbogbo àwọn tí ń gbé inú aṣálẹ̀; tí wọn ń fá apá kan irun orí wọn; nítorí pé bí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọnyi kò ṣe kọlà abẹ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ ilẹ̀ Israẹli kò kọlà ọkàn.”

10

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí OLUWA ń ba yín sọ, ẹ̀yin ọmọ Israẹli:

2 OLUWA ní, “Ẹ má kọ́ àṣà àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ẹ má sì páyà nítorí àwọn àmì ojú ọ̀run, bí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tilẹ̀ ń páyà nítorí wọn,

3 nítorí pé irọ́ ló wà nídìí àwọn àṣà wọn. Wọn á gé igi ninu igbó, agbẹ́gilére á fi àáké gbẹ́ ẹ.

4 Wọn á fi fadaka ati wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́, wọn á sì fi ìṣó kàn án mọ́lẹ̀, kí ó má baà wó lulẹ̀.

5 Ère wọn dàbí aṣọ́komásùn ninu oko ẹ̀gúsí, wọn kò lè sọ̀rọ̀, gbígbé ni wọ́n máa ń gbé wọn nítorí pé wọn kò lè dá rìn. Ẹ má bẹ̀rù wọn nítorí pé wọn kò lè ṣe ẹnikẹ́ni ní ibi kankan, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì lè ṣe rere.”

6 OLUWA, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ, o tóbi lọ́ba, agbára orúkọ rẹ sì pọ̀.

7 Ta ni kò ní bẹ̀rù rẹ, ìwọ ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí ẹ̀tọ́ rẹ ni; kò sì sí ẹni tí ó gbọ́n tó ọ láàrin àwọn ọlọ́gbọ́n tí wọ́n wà ní àwọn orílẹ̀-èdè, ati ni gbogbo ìjọba wọn.

8 Aláìmọ̀kan ati òmùgọ̀ ni gbogbo wọn, ère kò lè kọ́ eniyan lọ́gbọ́n, nítorí igi lásán ni.

9 Wọ́n kó fadaka pẹlẹbẹ wá láti ìlú Taṣiṣi, ati wúrà láti ìlú Ufasi. Iṣẹ́ ọwọ́ agbẹ́gilére ni wọ́n, ati ti àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà. Aṣọ wọn jẹ́ aláwọ̀ pupa ati ti elése àlùkò, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn oníṣọ̀nà ni gbogbo wọn.

10 Ṣugbọn OLUWA ni Ọlọrun tòótọ́, òun ni Ọlọrun alààyè, Ọba ayérayé. Tí inú rẹ̀ bá bẹ̀rẹ̀ síí ru ayé á mì tìtì, àwọn orílẹ̀-èdè kò lè farada ibinu rẹ̀.

11 Wí fún wọn pé àwọn ọlọrun tí kì í ṣe àwọn ni wọ́n dá ọ̀run ati ayé yóo parun láyé ati lábẹ́ ọ̀run.

12 Òun ni ó fi agbára rẹ̀ dá ayé, tí ó fi ọgbọ́n fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀, tí ó sì fi òye rẹ̀ ta ojú ọ̀run bí aṣọ.

13 Bí ó bá fọhùn, omi á máa rọ́kẹ̀kẹ̀ lójú ọ̀run, ó mú kí ìkùukùu gbéra láti òpin ayé, òun ni ó dá mànàmáná fún òjò, tí ó sì mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14 Òmùgọ̀ ni gbogbo eniyan jẹ́, wọn kò sì ní ìmọ̀; gbogbo àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà ni àwọn oriṣa wọn dójútì, nítorí pé irọ́ ló wà nídìí àwọn ère wọn; kò sí èémí ninu wọn.

15 Asán ni wọ́n, ohun ìṣìnà sì ni wọ́n; ní àkókò ìjẹníyà wọn, wọn yóo parun ni.

16 Ìpín Jakọbu kò rí bí àwọn wọnyi, nítorí òun ló dá ohun gbogbo, Israẹli sì ni ẹ̀yà tí ó yàn, gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀; OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀.

17 Ẹ gbé ẹrù yín nílẹ̀, ẹ̀yin tí ọ̀tá dótì wọnyi!

18 Nítorí OLUWA wí pé, “Mo ṣetán wàyí, tí n óo sọ àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ yìí nù bí òkò. N óo mú kí ìpọ́njú dé bá wọn, kí wọ́n lè mọ̀ pé nǹkan ṣe àwọn.”

19 Mo gbé, nítorí mo fara gbọgbẹ́! Ọgbẹ́ náà sì pọ̀. Ṣugbọn mo sọ fún ara mi pé, “Ìyà gan-an ni èyí jẹ́ fún mi, mo sì gbọdọ̀ fara dà á.”

20 Àgọ́ mi ti wó, gbogbo okùn rẹ̀ sì ti já. Àwọn ọmọ mi ti fi mí sílẹ̀, wọn kò sì sí mọ́. Kò sí ẹni tí yóo máa bá mi pa àgọ́ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóo máa bá mi ta aṣọ àgọ́ mi.

21 Nítorí pé òmùgọ̀ ni àwọn olùṣọ́-aguntan, wọn kò sì ṣe ìwádìí lọ́dọ̀ OLUWA, nítorí náà wọn kò ṣe àṣeyọrí, tí gbogbo agbo wọn sì fi túká.

22 Ẹ gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ kan! Ó ń tàn kálẹ̀! Ìdàrúdàpọ̀ ńlá ń bọ̀ láti ilẹ̀ àríwá, tí yóo sọ àwọn ìlú Juda di ahoro yóo sì di ibùgbé àwọn ajáko.

23 OLUWA, mo mọ̀ pé ọ̀nà ẹ̀dá kò sí ní ọwọ́ ara rẹ̀. Kò sí ní ìkáwọ́ ẹni tí ń rìn láti tọ́ ìṣísẹ̀ ara rẹ̀.

24 Tọ́ mi sọ́nà, OLUWA, ṣugbọn lọ́nà ẹ̀tọ́ ni kí o bá mi wí, kì í ṣe pẹlu ibinu rẹ, kí o má baà sọ mí di ẹni ilẹ̀.

25 Àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀ ọ́, ni kí o bínú sí kí ó pọ̀, ati àwọn tí wọn kì í jọ́sìn ní orúkọ rẹ; nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n jẹ ẹ́ ní àjẹrun patapata, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.

11

1 OLUWA bá èmi Jeremaya sọ̀rọ̀,

2 ó ní, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ majẹmu yìí, kí o sì sọ ọ́ fún àwọn ọmọ Juda, ati àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu.

3 Sọ fún wọn pé OLUWA Ọlọrun Israẹli ní, ‘Ẹnikẹ́ni tí kò bá gba ọ̀rọ̀ majẹmu

4 tí mo pa láṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, gbé! Majẹmu tí mo bá wọn dá ní ọjọ́ tí mo kó wọn kúrò ní ilẹ̀ Ijipti, ilẹ̀ tí ó gbóná bí iná tí alágbẹ̀dẹ fi ń yọ́ irin.’ Mo sọ fún wọn nígbà náà, mo ní, ‘Ẹ máa fetí sí ohùn mi, kí ẹ sì máa ṣe gbogbo nǹkan tí mo pa láṣẹ fun yín. Òun ni ẹ óo fi jẹ́ eniyan mi, tí èmi náà óo sì fi jẹ́ Ọlọrun yín.

5 Bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, n óo mú ẹ̀jẹ́ tí mo jẹ́ fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ, pé n óo fún wọn ní ilẹ̀ tí ó kún fún wàrà ati oyin,’ bí ó ti rí ní òní.” Mo bá dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, OLUWA.”

6 OLUWA tún sọ fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda ati ní àwọn òpópó Jerusalẹmu, pé kí wọn fetí sí ọ̀rọ̀ majẹmu yìí, kí wọ́n sì ṣe bí ó ti wí.

7 Mo kìlọ̀ fún àwọn baba ńlá yín ní ọjọ́ tí mo kó wọn kúrò ní ilẹ̀ Ijipti, títí tí ó sì fi di òní, n kò yé kìlọ̀ fún wọn pé kí wọ́n fetí sí ohùn èmi OLUWA.

8 Sibẹsibẹ wọn kò gbọ́; wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ mi. Kàkà bẹ́ẹ̀, olukuluku ń ṣe ohun tí ó wà ní ọkàn burúkú rẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe mú kí gbogbo ọ̀rọ̀ majẹmu yìí ṣẹ mọ́ wọn lára, bí mo ti pa á láṣẹ fún wọn pé kí wọn ṣe, ṣugbọn tí wọn kò ṣe.”

9 OLUWA tún wí fún mi pé, “Àwọn ọmọ Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu ń dìtẹ̀.

10 Wọ́n ti pada sí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, tí wọ́n kọ̀, tí wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Wọ́n ti bá àwọn ọlọrun mìíràn lọ, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ọmọ Israẹli ati àwọn ọmọ Juda ti da majẹmu tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá.

11 Nítorí náà, OLUWA ní, òun óo mú kí ibi ó dé bá wọn, ibi tí wọn kò ní lè bọ́ ninu rẹ̀. Ó ní bí wọ́n tilẹ̀ ké pe òun, òun kò ní fetí sí tiwọn.

12 Ó ní àwọn ìlú Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu yóo ké pe àwọn oriṣa tí wọn ń sun turari sí, ṣugbọn àwọn oriṣa kò ní lè gbà wọ́n lọ́jọ́ ìṣòro.

13 Bí àwọn ìlú ti pọ̀ tó ní ilẹ̀ Juda bẹ́ẹ̀ ni àwọn oriṣa ibẹ̀ pọ̀ tó. Bákan náà, Jerusalẹmu, bí òpópó ṣe pọ̀ tó ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ náà ni pẹpẹ tí wọ́n fi ń sun turari sí Baali, tí ó jẹ́ ohun ìtìjú, ṣe pọ̀ tó ninu rẹ̀.

14 “Nítorí náà, má ṣe gbadura fún àwọn eniyan wọnyi. Má sọkún nítorí wọn, má sì bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí n kò ní gbọ́, nígbà tí wọn bá ké pè mí nígbà ìṣòro wọn.

15 “Ẹ̀tọ́ wo ni olólùfẹ́ mi níláti wà ninu ilé mi lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ inú rẹ̀? Ṣé ọpọlọpọ ẹ̀jẹ́ ati ẹran tí a fi rúbọ lè mú kí ibi rékọjá rẹ̀? Ṣé ó lè máa yọ̀ nígbà náà?

16 Nígbà kan rí, OLUWA pè ọ́ ní igi olifi eléwé tútù, tí èso rẹ̀ dára; ṣugbọn pẹlu ìró ìjì ńlá, yóo dáná sun ún, gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ yóo sì jóná.

17 OLUWA àwọn ọmọ ogun tí ó gbìn ọ́, ti ṣe ìdájọ́ ibi fún ọ, nítorí iṣẹ́ ibi tí ẹ ṣe, ẹ̀yin ilé Israẹli ati ilé Juda; ẹ mú mi bínú nítorí pé ẹ sun turari sí oriṣa Baali.”

18 OLUWA fi iṣẹ́ ibi wọn hàn mí, ó sì yé mi.

19 Ṣugbọn mo dàbí ọ̀dọ́ aguntan tí wọn ń fà lọ sọ́dọ̀ alápatà. N kò mọ̀ pé nítorí mi ni wọ́n ṣe ń gbèrò ibi, tí wọn ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gé igi náà lulẹ̀ pẹlu èso rẹ̀, kí á gé e kúrò ní ilẹ̀ alààyè, kí á má sì ranti orúkọ rẹ̀ mọ́.”

20 Ṣugbọn onídàájọ́ òdodo ni ọ́, OLUWA àwọn ọmọ ogun, ẹni tí ó ń dán ọkàn ati èrò eniyan wò, jẹ́ kí n rí i bí o óo ṣe máa gbẹ̀san lára wọn; nítorí pé ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.

21 Nítorí náà, OLUWA sọ nípa àwọn ará Anatoti, tí wọn ń wá ẹ̀mí Jeremaya, tí wọn sì ń sọ fún un pé, “O kò gbọdọ̀ sọ àsọtẹ́lẹ̀ mọ́ ní orúkọ OLUWA. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa ni a óo pa ọ́.”

22 Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun ní òun óo jẹ wọ́n níyà; àwọn ọdọmọkunrin wọn yóo kú lójú ogun, ìyàn ni yóo sì pa àwọn ọmọkunrin ati ọmọbinrin wọn.

23 Kò ní sí ẹni tí yóo ṣẹ́kù nítorí pé òun óo mú kí ibi dé bá àwọn ará Anatoti, nígbà tí àkókò bá tó tí òun óo jẹ wọ́n níyà.

12

1 Olódodo ni ọ́, OLUWA, nígbà tí mo bá ń fẹjọ́ sùn ọ́; sibẹ n óo ro ẹjọ́ mi níwájú rẹ. Kí ló dé tí nǹkan ń dára fún àwọn eniyan burúkú?

2 O gbìn wọ́n, wọ́n ta gbòǹgbò; wọ́n dàgbà, wọ́n so èso; orúkọ rẹ kò jìnnà sẹ́nu wọn, ṣugbọn ọkàn wọn jìnnà sí ọ.

3 Ṣugbọn ìwọ OLUWA mọ̀ mí, O rí mi, o sì ti yẹ ọkàn mi wò o mọ èrò mi sí ọ. Fà wọ́n jáde bí aguntan tí wọn ń mú lọ pa, yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ ìparun.

4 Yóo ti pẹ́ tó, tí ilẹ̀ náà yóo máa ṣọ̀fọ̀, tí koríko oko yóo rọ? Nítorí iṣẹ́ burúkú àwọn tí wọn ń gbé inú rẹ̀, àwọn ẹranko ati àwọn ẹyẹ ṣègbé, nítorí àwọn eniyan ń wí pé, “Kò ní rí ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí wa.”

5 OLUWA ní, “Bí o bá àwọn tí ń fi ẹsẹ̀ sáré sáré, tí ó bá rẹ̀ ọ́, báwo ni o ṣe lè bá ẹṣin sáré? Bí o bá sì ń ṣubú ní ilẹ̀ tí ó tẹ́jú, báwo ni o óo ti ṣe nígbà tí o bá dé aṣálẹ̀ Jọdani?

6 Nítorí pé àwọn arakunrin rẹ pàápàá ati àwọn ará ilé baba rẹ ti hu ìwà ọ̀dàlẹ̀ sí ọ; àwọn gan-an ni wọ́n ń ṣe èké rẹ: Má gbẹ́kẹ̀lé wọn, bí wọ́n bá tilẹ̀ ń sọ̀rọ̀ rere sí ọ.”

7 OLUWA wí pé, “Mo ti kọ ilé mi sílẹ̀; mo ti kọ ogún tí a pín fún mi sílẹ̀. Mo ti fa ẹni tí ọkàn mi ń fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

8 Ogún mi ti dàbí kinniun inú igbó sí mi, ó ti sọ̀rọ̀ burúkú sí mi; nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.

9 Ṣé ogún mi ti dàbí ẹyẹ igún aláwọ̀ adíkálà ni? Ṣé àwọn ẹyẹ igún ṣùrù bò ó ni? Ẹ lọ pe gbogbo àwọn ẹranko igbó jọ, ẹ kó wọn wá jẹun.

10 Ọpọlọpọ àwọn darandaran ni wọ́n ti ba ọgbà àjàrà mi jẹ́, wọ́n ti tẹ oko mi mọ́lẹ̀, wọ́n sọ oko mi dáradára di aṣálẹ̀.

11 Wọ́n sọ ọ́ di ahoro, ilẹ̀ pàápàá ń ráhùn sí mi. Wọ́n ti sọ gbogbo ilẹ̀ náà di ahoro, ṣugbọn ẹnikẹ́ni kò bìkítà fún un.

12 Àwọn apanirun ti dé sí gbogbo àwọn òkè inú pápá, nítorí pé idà Ọlọrun ni ó ń run eniyan, jákèjádò ilẹ̀ náà; ẹnikẹ́ni kò ní alaafia,

13 Ọkà baali ni wọ́n gbìn, ṣugbọn ẹ̀gún ni wọ́n kórè. Wọ́n ṣe làálàá, ṣugbọn wọn kò jèrè kankan. Ojú yóo tì wọ́n nígbà ìkórè, nítorí ibinu gbígbóná OLUWA.”

14 Ohun tí OLUWA sọ nípa gbogbo àwọn aládùúgbò burúkú mi nìyí, àwọn tí wọn ń jí bù lára ilẹ̀ tí mo fún Israẹli, àwọn eniyan mi. Ó ní, “N óo kó wọn kúrò lórí ilẹ̀ wọn; n óo sì kó àwọn ọmọ Juda kúrò láàrin wọn.

15 Lẹ́yìn tí mo bá kó wọn kúrò tán, n óo pada ṣàánú wọn, n óo dá olukuluku pada sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.

16 Nígbà tí ó bá yá, bí wọ́n bá fi tọkàntọkàn kọ́ àṣà àwọn eniyan mi, tí wọ́n sì ń fi orúkọ mi búra, tí wọn ń wí pé, ‘Bí OLUWA Ọlọrun ti wà láàyè’, bí àwọn náà ṣe kọ́ àwọn eniyan mi láti máa fi orúkọ Baali búra, n óo fi ìdí wọn múlẹ̀ láàrin àwọn eniyan mi.

17 Ṣugbọn bí orílẹ̀-èdè kan bá ṣe àìgbọràn, n óo yọ ọ́ kúrò patapata, n óo sì pa á run. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

13

1 OLUWA sọ fún mi pé, “Lọ ra aṣọ funfun kan, kí o lọ́ ọ mọ́ ìdí, má sì tì í bọ omi rárá.”

2 Mo bá ra aṣọ funfun náà, bí OLUWA ti wí, mo lọ́ ọ mọ́ ìdí.

3 OLUWA tún sọ fún mi lẹẹkeji pé,

4 “Dìde, mú aṣọ funfun tí o rà, tí o lọ́ mọ́ ìdí, lọ sí odò Yufurate, kí o lọ fi pamọ́ sí ihò àpáta níbẹ̀.”

5 Mo bá lọ fi pamọ́ sí ẹ̀bá odò Yufurate bí OLUWA ti pa á láṣẹ fún mi.

6 Lẹ́yìn ọpọlọpọ ọjọ́, OLUWA sọ fún mi pé, “Dìde, lọ sí odò Yufurate kí o mú aṣọ tí mo ní kí o fi pamọ́ sibẹ wá.”

7 Mo bá lọ sí ẹ̀bá odò Yufurate; mo gbẹ́ ilẹ̀, mo yọ aṣọ funfun náà jáde kúrò ní ibi tí mo bò ó mọ́. Ó ti bàjẹ́; kò sì wúlò fún ohunkohun mọ́.

8 OLUWA sọ fún mi pé,

9 “Bẹ́ẹ̀ gan-an ni n óo ṣe sọ ògo Juda ati ti Jerusalẹmu di ìbàjẹ́.

10 Àwọn ẹni ibi wọnyi, tí wọ́n kọ̀, tí wọn kò gbọ́ tèmi, tí wọn ń fi oríkunkun tẹ̀lé ìfẹ́ ọkàn wọn, tí wọ́n sì ti sá tọ àwọn oriṣa lọ, tí wọn ń sìn wọ́n, tí wọn sì ń bọ wọ́n. Wọn yóo dàbí aṣọ yìí tí kò wúlò fún ohunkohun.

11 Bí aṣọ ìlọ́dìí tií lẹ̀ mọ́ ọkunrin lára, bẹ́ẹ̀ ni mo mú kí gbogbo ilé Israẹli ati gbogbo ilé Juda súnmọ́ mi, kí wọ́n lè jẹ́ eniyan mi, ati orúkọ mi, ìyìn mi, ati ògo mi. Ṣugbọn wọ́n kọ̀, wọn kò gbọ́.”

12 OLUWA ní, “Sọ fún wọn pé, èmi OLUWA Ọlọrun Israẹli ní, ‘Gbogbo ìkòkò ni a óo rọ ọtí waini kún.’ Wọn yóo dá ọ lóhùn pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìkòkò ni a óo rọ ọtí waini kún ni?’

13 Ìwọ wá wí fún wọn pé, èmi OLUWA ní n óo rọ àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ yìí ní ọtí àrọyó, ati àwọn ọba tí wọn jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, ati àwọn alufaa, àwọn wolii ati gbogbo àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu.

14 N óo máa sọ wọ́n lu ara wọn. Baba ati ọmọ yóo máa kọlu ara wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N kò ní ṣàánú wọn, n kò ní dá ẹnikẹ́ni sí, n kò sì ní yọ́nú sí wọn débi pé kí n má fẹ́ pa wọ́n run.”

15 Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ gbọ́, ẹ má gbéraga nítorí pé OLUWA ló sọ̀rọ̀.

16 Ẹ fi ògo fún OLUWA Ọlọrun yín kí ó tó mú òkùnkùn ṣú. Kí ẹ tó bẹ̀rẹ̀ sí fẹsẹ̀ kọ lórí òkè, níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀. Nígbà tí ẹ bá ń wá ìmọ́lẹ̀, yóo sọ ọ́ di ìṣúdudu, yóo sọ ọ́ di òkùnkùn biribiri.

17 Ṣugbọn bí ẹ kò bá ní gbọ́, ọkàn mi yóo sọkún níkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. N óo sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, omi yóo sì máa dà lójú mi, nítorí a ti kó agbo OLUWA ní ìgbèkùn.

18 Wí fún ọba ati ìyá ọba pé, “Ẹ sọ̀kalẹ̀ lórí ìtẹ́ yín, nítorí adé yín tí ó lẹ́wà ti ṣí bọ́ sílẹ̀ lórí yín.”

19 Wọ́n ti sé ìlẹ̀kùn odi àwọn ìlú ilẹ̀ Nẹgẹbu kò sì sí ẹni tí yóo ṣí wọn. A ti kó gbogbo Juda lọ sí ìgbèkùn, gbogbo wọn pátá ni a ti kó lọ.

20 Ẹ gbé ojú sókè, kí ẹ wo àwọn tí ń bọ̀ láti ìhà àríwá. Àwọn agbo ẹran tí a fun yín dà, àwọn ẹran ọ̀sìn yín tí ó lẹ́wà àwọn dà?

21 Kí ni ẹ óo máa wí nígbà tí OLUWA bá mú àwọn tí ẹ fi ṣe ọ̀rẹ́, tí ó fi wọ́n jọba le yín lórí? Ǹjẹ́ ìnira kò ní ba yín, bí ìrora obinrin tí ń rọbí?

22 Bí ẹ bá wí lọ́kàn yín pé, “Kí ló dé tí irú èyí fi dé bá wa?” Ẹ̀ṣẹ̀ yín ni ó pọ̀, ni a fi ká aṣọ ní ìdí yín, tí a sì jẹ yín níyà.

23 Ṣé ó ṣeéṣe kí ará Kuṣi yí àwọ̀ ara rẹ̀ pada? Àbí kí àmọ̀tẹ́kùn fọ tóótòòtóó ara rẹ̀ dànù? Bí ó bá ṣeéṣe, á jẹ́ wí pé ẹ̀yin náà lè hùwà rere; ẹ̀yin tí ibi ṣíṣe ti mọ́ lára.

24 N óo fọn yín ká bí ìyàngbò tí afẹ́fẹ́ láti inú aṣálẹ̀ ń fẹ́ kiri.

25 Èyí ni ìpín yín, ìpín tí mo ti yàn fun yín, nítorí pé ẹ ti gbàgbé èmi OLUWA, ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ọlọrun èké.

26 Èmi gan-an ni n óo ká aṣọ lára yín, n óo sì fi bò yín lójú, kí ayé lè rí ìhòòhò yín.

27 Mo ti rí ìwà ìbàjẹ́ yín, gbogbo ìwà àgbèrè yín, bí ẹ tí ń yan ká bí akọ ẹṣin, ati ìwà ìṣekúṣe yín ní orí àwọn òkè ninu pápá. Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ẹ gbé! Yóo ti pẹ́ tó kí á tó wẹ̀ yín mọ́?

14

1 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA sọ fún Jeremaya nípa ọ̀gbẹlẹ̀ nìyí:

2 “Juda ń ṣọ̀fọ̀, àwọn ẹnubodè ìlú rẹ̀ wà ninu ìnira. Àwọn eniyan inú rẹ̀ ń sọkún ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀, igbe àwọn ará Jerusalẹmu sì ta sókè.

3 Àwọn ọlọ́lá ní ìlú rán àwọn iranṣẹ wọn lọ pọn omi, àwọn iranṣẹ dé odò, wọn kò rí omi. Wọ́n gbé ìkòkò omi wọn pada lófìfo, ojú tì wọ́n, ìdààmú dé bá wọn, wọ́n káwọ́ lérí.

4 Nítorí ilẹ̀ tí ó gbẹ, nítorí òjò tí kò rọ̀ ní ilẹ̀ náà, ojú ti àwọn àgbẹ̀, wọ́n káwọ́ lérí.

5 Àgbọ̀nrín inú igbó pàápàá já ọmọ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, nítorí kò sí koríko.

6 Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè, wọ́n ń mí hẹlẹhẹlẹ bí ajáko. Ojú wọn rẹ̀wẹ̀sì, nítorí kò sí koríko.

7 Àwọn eniyan mi ké pè mí wí pé, ‘Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa ń jẹ́rìí lòdì sí wa, sibẹsibẹ, nítorí orúkọ rẹ, gbà wá. Ọpọlọpọ ìgbà ni a ti pada lẹ́yìn rẹ, a ti ṣẹ̀ ọ́.

8 Ìwọ ìrètí Israẹli, olùgbàlà rẹ̀ ní ìgbà ìṣòro. Kí ló dé tí o óo fi dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà? Àní, bí èrò ọ̀nà, tí ó yà láti sùn mọ́jú?

9 Kí ló dé tí o fi dàbí ẹni tí ìdààmú bá; bí alágbára tí kò lè gbani là? Bẹ́ẹ̀ ni o wà láàrin wa, OLUWA, a sì ń fi orúkọ rẹ pè wá, má fi wá sílẹ̀.’ ”

10 OLUWA sọ nípa àwọn eniyan náà pé, “Ó wù wọ́n láti máa ṣáko kiri, wọn kò ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ wọn; nítorí náà wọn kì í ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ OLUWA, nisinsinyii OLUWA yóo ranti àìdára wọn, yóo sì jẹ wọ́n níyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”

11 OLUWA sọ fún mi pé, “Má gbadura pé kí àwọn eniyan wọnyi wà ní alaafia.

12 Wọn ìbáà gbààwẹ̀, n kò ní gbọ́ igbe wọn. Wọn ìbáà rú ẹbọ sísun ati ẹbọ ohun jíjẹ, n kò ní tẹ́wọ́ gbà wọ́n. Idà, ati ebi, ati àjàkálẹ̀ àrùn, ni n óo fi pa wọ́n run.”

13 Mo bá dáhùn pé, “Háà! OLUWA Ọlọrun, wò ó! Àwọn wolii ń sọ fún wọn pé, wọn kò ní fojú kan ogun, tabi ìyàn, ati pé, alaafia tòótọ́ ni o óo fún wọn ní ibí yìí.”

14 OLUWA bá sọ fún mi pé, “Àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ ni àwọn wolii ń sọ ní orúkọ mi, n kò rán wọn níṣẹ́, n kò fún wọn láṣẹ, n kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí; iṣẹ́ asán ni wọ́n ń wò. Ohun tí ó wà lọ́kàn wọn ni wọ́n ń sọ.

15 Nítorí náà, ohun tí èmi OLUWA sọ ni pé, àwọn wolii tí n kò rán níṣẹ́, tí wọn ń jíṣẹ́ orúkọ mi, tí wọn ní èmi sọ pé ogun ati ìyàn kò ní wọ ilẹ̀ yìí, ogun ati ìyàn ni yóo pa àwọn gan-an run.

16 Wọn óo gbé àwọn eniyan tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún sọ síta ní òkú ní ìgboro Jerusalẹmu, nígbà tí ìyàn ati ogun bá pa wọ́n tán. Kò ní sí ẹni tí yóo sin òkú wọn, ati ti àwọn iyawo wọn, ati ti àwọn ọmọ wọn lọkunrin ati lobinrin. N óo da ibi tí wọ́n ṣe lé wọn lórí.”

17 OLUWA wí fun mi pé, “Sọ fún wọn pé, ‘Kí omijé máa ṣàn lójú mi tọ̀sán-tòru, kí ó má dáwọ́ dúró, nítorí ọgbẹ́ ńlá tí a fi tagbára tagbára ṣá eniyan mi.

18 Bí mo bá jáde lọ sí ìgbèríko, àwọn tí wọ́n fi idà pa ni wọ́n kún bẹ̀! Bí mo bá sì wọ ààrin ìlú, àwọn tí ìyàn di àìsàn sí lára ni wọ́n kún bẹ̀. Nítorí àwọn wolii ati àwọn alufaa ń lọ káàkiri gbogbo ilẹ̀ náà, wọn kò sì mọ ohun tí wọn ń ṣe.’ ”

19 OLUWA, ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ patapata ni? Àbí Sioni ti di ohun ìríra lọ́kàn rẹ? Kí ló dé tí o fi lù wá, tóbẹ́ẹ̀ tí ọ̀rọ̀ tiwa kọjá ìwòsàn? À ń retí alaafia, ṣugbọn ire kankan kò dé. À ń retí àkókò ìwòsàn, ṣugbọn ìpayà ni a rí.

20 OLUWA, a mọ ìwà burúkú wa, ati ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa, nítorí a ti ṣẹ̀ ọ́.

21 Má ta wá nù nítorí orúkọ rẹ, má sì fi àbùkù kan ìtẹ́ rẹ tí ó lógo. Ranti majẹmu tí o bá wa dá, ranti, má sì ṣe dà á.

22 Ninu gbogbo àwọn ọlọrun èké tí àwọn orílẹ̀-èdè ń sìn, ǹjẹ́ ọ̀kan wà tí ó lè mú kí òjò rọ̀? Àbí ojú ọ̀run ní ń fúnrarẹ̀ rọ ọ̀wààrà òjò? OLUWA Ọlọrun wa, ṣebí ìwọ ni? Ìwọ ni a gbẹ́kẹ̀lé, nítorí ìwọ ni o ṣe gbogbo nǹkan wọnyi.

15

1 OLUWA bá tún sọ fún mi pé, “Mose ati Samuẹli ìbáà wá dúró níwájú mi, ọkàn mi kò lè yọ́ sí àwọn eniyan wọnyi. Lé wọn kúrò níwájú mi, kí wọ́n máa lọ!

2 Bí wọ́n bá bi ọ́ pé níbo ni kí àwọn ó lọ, sọ fún wọn pé èmi OLUWA ní, ‘Àwọn tí wọn yóo kú ikú àjàkálẹ̀ àrùn, kì àjàkálẹ̀ àrùn pa wọ́n; àwọn tí wọn yóo kú ikú ogun, kí ogun pa wọ́n. Àwọn tí wọn yóo kú ikú ìyàn, kí ìyàn pa wọ́n; àwọn tí wọn yóo lọ sí ìgbèkùn, kí ogun kó wọn lọ.’

3 Oríṣìí ìparun mẹrin ni n óo jẹ́ kí ó dé bá wọn: idà óo pa wọ́n, ajá óo fà wọ́n ya, àwọn ẹyẹ ati àwọn ẹranko óo jẹ wọ́n ní àjẹrun.

4 N óo sọ wọ́n di ohun tí ó bani lẹ́rù fún gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé, nítorí ohun tí Manase, ọmọ Hesekaya, ọba Juda, ṣe ní Jerusalẹmu.”

5 OLUWA ní, “Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ta ni yóo ṣàánú yín? Ta ni yóo dárò yín? Ta ni yóo ya ọ̀dọ̀ yín, láti bèèrè alaafia yín?

6 Ẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń pada lẹ́yìn mi; èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe na ọwọ́ ibinu mi si yín, tí mo sì pa yín run. Mo ti mú sùúrù, ó ti sú mi.

7 Mo ti fẹ́ wọn bí ẹni fẹ́ ọkà ní ibi ìpakà, ní ẹnubodè ilẹ̀ náà. Mo ti kó ọ̀fọ̀ bá wọn; mo ti pa àwọn eniyan mi run, nítorí wọn kò yipada kúrò ní ọ̀nà wọn.

8 Mo ti mú kí opó pọ̀ láàrin wọn ju iyanrìn inú òkun lọ. Mo mú kí apanirun gbógun ti àwọn ìyá àwọn ọdọmọkunrin ní ọ̀sán gangan. Mo mú kí ìbẹ̀rù ati ìwárìrì já lù wọ́n láìròtẹ́lẹ̀.

9 Ẹni tí ó bí ọmọ meje ṣe àárẹ̀, ó sì dákú, oòrùn rẹ̀ wọ̀ lọ́sàn-án gangan. Ìtìjú ati àbùkù bá a. N óo jẹ́ kí ọ̀tá fi idà pa àwọn tí wọ́n kù ninu wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

10 Mo gbé! Ìyá mi, kí ló dé tí o bí mi, èmi tí mo di oníjà ati alárìíyànjiyàn láàrin gbogbo ìlú! N kò yá ẹnikẹ́ni lówó, bẹ́ẹ̀ n kò yáwó lọ́wọ́ ẹnìkan, sibẹsibẹ gbogbo wọn ni wọ́n ń ṣépè lé mi.

11 Kí èpè wọn mọ́ mi, OLUWA, bí n kò bá sọ ọ̀rọ̀ wọn ní rere níwájú rẹ, bí n kò bá gbadura fún àwọn ọ̀tá mi ní àkókò ìyọnu ati ìdààmú wọn.

12 Ǹjẹ́ ẹnìkan lè ṣẹ́ irin, pàápàá, irin ilẹ̀ àríwá tí wọn fi idẹ lú?

13 OLUWA bá dáhùn pé, “Nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, n óo fi ọrọ̀ ati ohun ìṣúra rẹ fún àwọn tí ń kó ìkógun ní gbogbo agbègbè rẹ, láìgba owó lọ́wọ́ wọn.

14 N óo mú kí o sin àwọn ọ̀tá rẹ ní ilẹ̀ tí o kò dé rí. Mo ti fi ibinu dá iná kan, ó ti ràn, yóo máa jó ọ, kò sì ní kú laelae.”

15 Mo bá dáhùn pé, “OLUWA, ṣebí ìwọ náà mọ̀? Ranti mi, kí o sì ràn mí lọ́wọ́. Gbẹ̀san mi lára àwọn tí wọn ń ṣe inúnibíni sí mi. Má mú mi kúrò nítorí ojú àánú rẹ. Ranti pé nítorí rẹ ni wọ́n ṣé ń fi mí ṣẹ̀sín.

16 Nígbà tí mo rí ọ̀rọ̀ rẹ, mo fi ṣe oúnjẹ jẹ. Nǹkan ayọ̀ ni ọ̀rọ̀ rẹ jẹ́ fún mi, ó sì jẹ́ ìdùnnú ọkàn mi. Nítorí orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun.

17 N kò jókòó láàrin àwọn alárìíyá, bẹ́ẹ̀ ni n kò yọ̀. Mo dá jókòó nítorí àṣẹ rẹ, nítorí o ti fi ìrúnú kún ọkàn mi.

18 Kí ló dé tí ìrora mi kò dáwọ́ dúró, tí ọgbẹ́ mi jinlẹ̀, tí ó kọ̀, tí kò san? Ṣé o fẹ́ dá mi lọ́kàn le lásán ni; bí ẹlẹ́tàn odò tíí gbẹ nígbà ẹ̀ẹ̀rùn?”

19 Nítorí náà OLUWA ní, “Bí o bá yipada, n óo mú ọ pada sípò rẹ, o óo sì tún máa ṣe iranṣẹ mi. Bí o bá bẹ̀rẹ̀ sí sọ ọ̀rọ̀ gidi, tí o dákẹ́ ìsọkúsọ, o óo tún pada di òjíṣẹ́ mi. Àwọn ni yóo pada tọ̀ ọ́ wá, o kò ní tọ̀ wọ́n lọ.

20 N óo sọ ọ́ di odi alágbára tí a fi idẹ mọ, lọ́dọ̀ àwọn eniyan wọnyi. Wọn yóo gbógun tì ọ́, ṣugbọn wọn kò ní ṣẹgun rẹ, nítorí pé mo wà pẹlu rẹ láti gbà ọ́, ati láti yọ ọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

21 N óo gbà ọ́ lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú, n óo sì rà ọ́ pada lọ́wọ́ àwọn ìkà, aláìláàánú eniyan.”

16

1 OLUWA tún bá mi sọ̀rọ̀, ó ní:

2 “O kò gbọdọ̀ fẹ́ iyawo tabi kí o bímọ ní ibí yìí.

3 Nítorí ohun tí OLUWA sọ nípa àwọn ọmọkunrin ati àwọn ọmọbinrin tí a bí ní ibí yìí, ati nípa ìyá tí ó bí wọn, ati baba tí a bí wọn fún ni pé,

4 àìsàn burúkú ni yóo pa wọ́n. Ẹnìkan kò ní ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní sin wọ́n; bí ìgbọ̀nsẹ̀ ni wọn yóo rí lórí ilẹ̀. Ogun ati ìyàn ni yóo pa wọ́n run, òkú wọn yóo sì di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ati àwọn ẹranko.

5 “Má wọ ilé tí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀, má lọ máa kọrin arò, tabi kí o bá wọn kẹ́dùn, nítorí mo ti mú alaafia mi ati ìfẹ́ mi ati àánú mi kúrò lọ́dọ̀ àwọn eniyan wọnyi.

6 Àtàwọn eniyan pataki pataki, ati mẹ̀kúnnù, ni yóo kú ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní rí ẹni sin òkú wọn, kò ní sí ẹni tí yóo sọkún wọn; ẹnìkan kò ní fi abẹ ya ara, tabi kí ẹnìkan fá orí nítorí wọn.

7 Kò ní sí ẹni tí yóo fún ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní oúnjẹ láti tù ú ninu, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò sì ní bu omi fún ẹnìkan mu, nítorí ikú baba tabi ìyá rẹ̀.

8 “O kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí wọ́n ti ń se àsè, má bá wọn jókòó láti jẹ tabi láti mu.

9 Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní: ‘Wò ó! N óo fi òpin sí ẹ̀rín ati ìró ayọ̀ ní ibí yìí, n óo sì fi òpin sí ohùn iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé ati ti ọkọ iyawo. Yóo ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ níṣojú yín, ní ìgbà ayé yín.’

10 “Bí o bá sọ ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn eniyan náà tán, bí wọn bá bi ọ́ pé, ‘Kí ló dé tí OLUWA fi sọ gbogbo ọ̀rọ̀ burúkú yìí nípa wa? Kí ni a ṣe? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni a ṣẹ OLUWA Ọlọrun wa?’

11 Kí o dá wọn lóhùn pé, nítorí pé àwọn baba wọn ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n ń tẹ̀lé àwọn ọlọrun mìíràn, wọ́n ń sìn wọ́n, wọ́n sì ń bọ wọ́n.

12 Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọn kò sì pa òfin mi mọ́. Ẹ̀yin gan-an ti ṣe ohun tí ó burú ju ti àwọn baba yín lọ, ẹ wò bí olukuluku yín tí ń tẹ̀lé agídí ọkàn rẹ̀, tí ẹ kọ̀, tí ẹ kò sì gbọ́ tèmi.

13 Nítorí náà, n óo gba yín dànù kúrò ní ilẹ̀ yìí; n óo fọn yín dànù bí òkò, sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ati àwọn baba yín kò mọ̀ rí. Níbẹ̀ ni ẹ óo ti máa sin oriṣa, tí ẹ óo máa bọ wọ́n tọ̀sán-tòru, nítorí pé n kò ní ṣàánú yín.”

14 Nítorí náà, OLUWA ní, “Àkókò ń bọ̀, tí wọn kò ní máa búra mọ́ pé, ‘Bí OLUWA, tí ó kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti tí ń bẹ,’

15 ṣugbọn wọn yóo máa búra pé, ‘Bí OLUWA tí ń bẹ, ẹni tí ó kó àwọn ọmọ Israẹli jáde láti ilẹ̀ àríwá ati láti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó lé wọn lọ.’ N óo mú wọn pada sórí ilẹ̀ wọn, ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba wọn.”

16 Ó ní, “Wò ó, n óo ranṣẹ pe ọpọlọpọ apẹja, wọn yóo sì wá kó àwọn eniyan wọnyi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Lẹ́yìn náà, n óo ranṣẹ sí ọpọlọpọ ọdẹ, wọn yóo sì wá dọdẹ wọn ní orí gbogbo òkè gíga ati àwọn òkè kéékèèké, ati ninu pàlàpálá àpáta.

17 Nítorí pé mò ń wo gbogbo ohun tí wọn ń ṣe, kò sí èyí tí n kò rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò sápamọ́ fún mi.

18 N óo gbẹ̀san àìdára wọn, ati ẹ̀ṣẹ̀ wọn ní ìlọ́po meji, nítorí wọ́n ti fi ohun ìríra wọn sọ ilẹ̀ mi di eléèérí. Wọ́n sì ti kó oriṣa ìríra wọn kún ilẹ̀ mi.”

19 OLUWA, ìwọ ni agbára mi, ati ibi ààbò mi, ìwọ ni ibi ìsápamọ́sí mi, ní ìgbà ìpọ́njú. Àwọn orílẹ̀-èdè yóo wá sọ́dọ̀ rẹ, láti gbogbo òpin ayé, wọn yóo máa wí pé: “Irọ́ patapata ni àwọn baba wa jogún, ère lásánlàsàn tí kò ní èrè kankan.

20 Ṣé eniyan lè fi ọwọ́ ara rẹ̀ ṣẹ̀dá ọlọrun? Irú ọlọrun bẹ́ẹ̀ kì í ṣe ọlọrun rárá.”

21 OLUWA ní, “Nítorí náà, wò ó, n óo jẹ́ kí wọn mọ̀; àní sẹ́, n óo jẹ́ kí wọ́n mọ agbára ati ipá mi; wọn yóo sì mọ̀ pé orúkọ mi ni OLUWA.”

17

1 OLUWA ní, “Gègé irin ni a fi kọ ẹ̀ṣẹ̀ Juda sílẹ̀ gègé òkúta dayamọndi ni a sì fi kọ ọ́ sí ọkàn yín, ati sí ara ìwo ara pẹpẹ wọn,

2 níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá ń ranti àwọn pẹpẹ yín, ati àwọn oriṣa Aṣera yín, tí ẹ rì mọ́ ẹ̀gbẹ́ gbogbo igi tútù, ati lórí àwọn òkè gíga;

3 ati lórí àwọn òkè ninu pápá. N óo sọ gbogbo ọrọ̀ yín ati gbogbo ohun ìṣúra yín di ìkógun fún àwọn ọ̀tá yín; n óo fi gbẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ yín ní gbogbo ilẹ̀ yín.

4 Ìwà yín yóo mú kí ilẹ̀ tí mo fun yín bọ́ lọ́wọ́ yín; n óo sí sọ yín di ẹrú àwọn ọ̀tá yín ní ilẹ̀ tí ẹ kò mọ̀rí. Ẹ ti mú kí ibinu mi máa jó bí iná, kò sì ní kú títí lae.”

5 OLUWA ní, “Ègún ni fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé eniyan, tí ó fi ẹlẹ́ran ara ṣe agbára rẹ̀; tí ọkàn rẹ̀ yipada kúrò lọ́dọ̀ èmi OLUWA.

6 Ó dàbí igbó ṣúúrú ninu aṣálẹ̀, nǹkan rere kan kò lè ṣẹlẹ̀ sí i. Ninu ilẹ̀ gbígbẹ, ninu aṣálẹ̀ ni ó wà, ninu ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè gbé.

7 “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, tí ó fi OLUWA ṣe àgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.

8 Yóo dàbí igi tí a gbìn sí ipa odò, tí ó ta gbòǹgbò kan ẹ̀bá odò. Ẹ̀rù kò ní bà á nígbà tí ẹ̀ẹ̀rùn bá dé, nítorí pé ewé rẹ̀ yóo máa tutù minimini. Kò ní páyà lákòókò ọ̀gbẹlẹ̀, nígbà gbogbo ni yóo sì máa so.

9 “Ọkàn eniyan kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ìwà ìbàjẹ́ sì kún inú rẹ̀; ta ni ó lè mọ èrò ọkàn eniyan?

10 Èmi OLUWA ni èmi máa ń wádìí èrò eniyan, tí èmi sì máa ń yẹ ọkàn eniyan wò, láti san án fún olukuluku gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀, ati gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11 Bí àparò tíí pa ẹyin ẹlẹ́yin bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó fi èrú kó ọrọ̀ jọ. Ọrọ̀ yóo lọ mọ́ ọn lọ́wọ́ lọ́sàn-án gangan, nígbẹ̀yìn yóo di òmùgọ̀.

12 Ìtẹ́ ògo tí a tẹ́ sí ibi gíga láti ìbẹ̀rẹ̀ ni ibi mímọ́ wa.

13 OLUWA, ìwọ ni Israẹli gbójú lé, ojú yóo ti gbogbo àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀. A óo kọ orúkọ àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀ sórí ilẹ̀, yóo sì parẹ́, nítorí pé wọ́n ti kọ OLUWA, orísun omi ìyè, sílẹ̀.

14 Wò mí sàn, OLUWA, ara mi yóo sì dá, gbà mí, n óo sì bọ́ ninu ewu. Nítorí pé ìwọ ni mò ń yìn.

15 Wò ó! Wọ́n ń bi mí pé, “Níbo ni gbogbo ìhàlẹ̀ OLUWA já sí? Jẹ́ kí ó ṣẹ, kí á rí i!”

16 N kò bẹ̀bẹ̀ pé kí o rán ibi sí wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò fẹ́ ọjọ́ ibi fún wọn. OLUWA, o mọ̀ bẹ́ẹ̀. Ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde kò tún lè ṣàjèjì sí ọ.

17 Má di ohun ẹ̀rù fún mi, nítorí ìwọ ni ibi ààbò mi ní ọjọ́ ibi.

18 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn tí wọn ń ṣe inúnibíni mi, ṣugbọn kí ojú má tì mí. Jẹ́ kí ìpayà bá wọn, ṣugbọn má jẹ́ kí èmi páyà. Mú ọjọ́ ibi dé bá wọn; pa wọ́n run ní àpatúnpa.

19 OLUWA sọ fún mi pé, “Lọ dúró ní ẹnubodè Bẹnjamini níbí, tí àwọn ọba Juda máa ń gbà wọlé, tí wọn sìí gbà jáde; ati ní gbogbo ẹnubodè Jerusalẹmu,

20 kí o wí pé, ‘Ẹ gbọ́ bí OLUWA ti wí, ẹ̀yin ọba Juda, ati gbogbo ẹ̀yin ará Juda ati gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gba ẹnu ọ̀nà wọnyi wọlé.

21 OLUWA ní kí ẹ ṣọ́ra fún ẹ̀mí yín, ẹ má máa ru ẹrù ní ọjọ́ ìsinmi, ẹ má gbé ẹrù wọ ẹnubodè Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.

22 Ẹ kò gbọdọ̀ ru ẹrù jáde ní ilé yín ní ọjọ́ ìsinmi. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, ẹ níláti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, bí mo ti pa á láṣẹ fún àwọn baba ńlá yín.

23 Sibẹ àwọn baba yín kò gbọ́; wọn kò sì fetí sílẹ̀, wọ́n ṣe oríkunkun, kí wọn má baà gbọ́, kí wọn má baà gba ìtọ́ni.

24 Ṣugbọn bí ẹ̀yin bá fetí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò gbé ẹrù wọ inú ìlú yìí lọ́jọ́ ìsinmi, tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́ láìṣe iṣẹ́ kankan lọ́jọ́ náà,

25 àwọn ọba tí yóo máa gúnwà lórí ìtẹ́ Dafidi, yóo máa gba ẹnubodè ìlú yìí wọlé. Àwọn ati àwọn ìjòyè wọn, ati àwọn ará Juda ati ará ìlú Jerusalẹmu yóo máa gun ẹṣin ati kẹ̀kẹ́ ogun wọlé. Àwọn eniyan yóo sì máa gbé ìlú yìí títí ayé.

26 Àwọn eniyan yóo máa wá láti gbogbo ìlú Juda ati àwọn agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Bẹnjamini ati pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ṣefela, láti àwọn agbègbè olókè ati ilẹ̀ Nẹgẹbu, wọn yóo máa mú ẹbọ sísun ati ẹbọ ọrẹ wá, pẹlu ẹbọ ohun jíjẹ ati turari; wọn yóo máa mú ẹbọ ọpẹ́ wá sí ilé OLUWA.

27 Ṣugbọn bí ẹ kò bá fetí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, tí ẹ̀ ń ru ẹrù wọ inú Jerusalẹmu lọ́jọ́ ìsinmi, n óo ṣá iná sí ẹnubodè Jerusalẹmu, yóo jó àwọn ààfin rẹ̀, kò sì ní ṣe é pa.’ ”

18

1 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀, ó ní:

2 “Dìde, lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni óo ti gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ.”

3 Mo bá lọ sí ilé amọ̀kòkò. Mo bá a tí ó ń mọ ìkòkò kan lórí òkúta tí wọn fi ń mọ ìkòkò.

4 Ìkòkò tí ó ń fi amọ̀ mọ bàjẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀, ó bá fi amọ̀ náà mọ ìkòkò mìíràn, tí ó wù ú.

5 OLUWA bá sọ fún mi pé,

6 “Ẹ̀yin ilé Israẹli, ṣé n kò lè ṣe yín bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe ìkòkò tí ó mọ ni? Bí amọ̀ ti rí lọ́wọ́ amọ̀kòkò ni ẹ rí lọ́wọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.

7 Bí mo bá sọ pé n óo fa orílẹ̀-èdè kan, tabi ìjọba kan tu, n óo wó o lulẹ̀, n óo sì pa á run,

8 bí orílẹ̀-èdè ọ̀hún bá yipada kúrò ninu ìwà burúkú rẹ̀, n óo dá ibi tí mo ti fẹ́ ṣe sí i tẹ́lẹ̀ dúró.

9 Bí mo bá sọ pé n óo gbé orílẹ̀-èdè kan dìde, n óo sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀;

10 bí ó bá ṣe nǹkan burúkú lójú mi, tí kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu, n óo dá nǹkan rere tí mo ti fẹ́ ṣe fún un dúró.

11 Nítorí náà, sọ fún àwọn ará Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu pé, èmi OLUWA ní, mò ń pète ibi kan si yín, mo sì ń pinnu rẹ̀ lọ́wọ́ báyìí, kí olukuluku yín yipada kúrò ninu ibi tí ó ń ṣe; kí ẹ sì tún ìwà ati ìṣe yín ṣe.

12 Ṣugbọn wọ́n ń wí pé, ‘Rárá o, OLUWA kàn ń sọ tirẹ̀ ni, tinú wa ni a óo ṣe, olukuluku yóo máa lo agídí ọkàn rẹ̀.’ ”

13 Nítorí náà OLUWA ní, “Ẹ bèèrè láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè, bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ irú rẹ̀ rí. Israẹli ti ṣe ohun tó burú gan-an.

14 Ṣé yìnyín òkè Lẹbanoni a máa dà ní pàlàpálá Sirioni? Àbí omi tútù tí máa ń ṣàn láti inú òkè rẹ̀ a máa gbẹ?

15 Ṣugbọn àwọn eniyan mi ti gbàgbé mi, wọ́n ń sun turari sí oriṣa èké. Wọ́n ti kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà àtijọ́ tí wọn ń tọ̀, wọ́n ti yà sí ọ̀nà ojúgbó tí kì í ṣe ojú ọ̀nà tààrà.

16 Wọ́n sọ ilẹ̀ wọn di ohun ẹ̀rù ati ohun àrípòṣé títí lae. Gbogbo àwọn tí wọn bá gba ibẹ̀ kọjá ni ẹ̀rù yóo máa bà, tí wọn yóo sì máa mi orí.

17 N óo fọ́n wọn ká níwájú ọ̀tá bí ẹ̀fúùfù ìlà oòrùn. Ẹ̀yìn ni n óo kọ sí wọn lọ́jọ́ àjálù, wọn kò ní rí ojú mi.”

18 Wọ́n bá dáhùn pé, “Ẹ wá, kí á gbìmọ̀ ibi sí Jeremaya, nítorí pé òfin kò ní parun lọ́dọ̀ àwọn alufaa, ìmọ̀ràn kò ní tán lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, ọ̀rọ̀ Ọlọrun kò sì ní ṣàì máa wà lẹ́nu àwọn wolii. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á fi ọ̀rọ̀ ẹnu wa pa á, ẹ má sì jẹ́ kí á fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kankan.”

19 Mo bá gbadura pe, “Tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, OLUWA, kí o sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi.

20 Ṣé ibi ni eniyan fi í san rere? Sibẹ wọ́n ti wa kòtò sílẹ̀ fún mi. Ranti bí mo ti dúró níwájú rẹ tí mo sọ ọ̀rọ̀ wọn ní rere, kí o baà lè yí ibinu rẹ pada lórí wọn.

21 Nítorí náà ìyàn ni kí ó pa àwọn ọmọ wọn, kí ogun pa wọ́n, kí àwọn aya wọn di aláìlọ́mọ ati opó, kí àjàkálẹ̀ àrùn pa àwọn ọmọkunrin wọn, kí idà ọ̀tá sì pa àwọn ọ̀dọ̀ wọn lójú ogun.

22 Kí igbe ẹkún ó sọ ninu ilé wọn, nígbà tí o bá mú àwọn apanirun wá sórí wọn lójijì; nítorí pé wọ́n wa kòtò láti mú mi, wọ́n dẹ tàkúté sílẹ̀ fún mi.

23 OLUWA, gbogbo àbá tí wọn ń dá ni o mọ̀, o mọ gbogbo ète tí wọn ń pa láti pa mí. Má dárí ìwà ibi wọn jì wọ́n, má sì pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ níwájú rẹ. Jẹ́ kí wọn ṣubú níwájú rẹ, nígbà tí inú bá ń bí ọ ni kí o bá wọn wí.”

19

1 OLUWA ní kí n lọ ra ìgò amọ̀ kan, kí n mú díẹ̀ ninu àwọn àgbààgbà ìlú ati àwọn bíi mélòó kan ninu àwọn àgbà alufaa,

2 kí n lọ sí ìsàlẹ̀ àfonífojì ọmọ Hinomu, lẹ́nu Ibodè Àpáàdì; kí n sì kéde ọ̀rọ̀ tí òun óo sọ fún mi níbẹ̀:

3 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ̀yin ọba Juda ati ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní òun óo mú ibi kan wá sórí ilẹ̀ yìí, híhó ni etí gbogbo àwọn tí wọn bá gbọ́ nípa rẹ̀ yóo máa hó.

4 Nítorí pé àwọn eniyan wọnyi ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n ti sọ ibí di aláìmọ́ pẹlu turari tí wọn ń sun sí àwọn oriṣa tí àwọn, ati àwọn baba wọn, ati àwọn ọba Juda kò mọ̀ rí. Wọ́n ti pa àwọn aláìṣẹ̀ sí gbogbo ibí yìí.

5 Wọ́n kọ́ pẹpẹ oriṣa Baali, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọkunrin wọn rú ẹbọ sísun sí i. N kò pàṣẹ fún wọn pé kí wọn máa ṣe bẹ́ẹ̀, n kò fún wọn ní irú ìlànà bẹ́ẹ̀; ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀ kò tilẹ̀ wá sí mi lọ́kàn.

6 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀, tí a kò ní pe ibí yìí ní Tofeti tabi àfonífojì ọmọ Hinomu mọ́. Àfonífojì ìpànìyàn ni a óo máa pè é.

7 N óo sọ ìmọ̀ àwọn ará Juda ati ti àwọn ará ìlú Jerusalẹmu di òfo, n óo jẹ́ kí àwọn ọ̀tá wọn ati àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí wọn fi idà pa wọ́n. N óo sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ati àwọn ẹranko.

8 N óo sì sọ ìlú yìí di ohun ẹ̀rù ati àrípòṣé, ẹ̀rù ìlú náà yóo sì máa ba gbogbo ẹni tí ó bá kọjá níbẹ̀, wọn yóo máa pòṣé nítorí àjálù tí ó dé bá a.

9 N óo mú kí wọn máa pa ọmọ wọn ọkunrin ati obinrin jẹ. Olukuluku yóo máa pa aládùúgbò rẹ̀ jẹ nítorí ìdààmú tí àwọn ọ̀tá wọn, ati àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn yóo kó bá wọn, nígbà tí ogun bá dótì wọ́n.”

10 OLUWA ní lẹ́yìn náà kí n fọ́ ìgò amọ̀ náà ní ojú àwọn ọkunrin tí wọ́n wà pẹlu mi,

11 kí n sì sọ fún wọn pé, OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Bí ẹni fọ́ ìkòkò amọ̀ ni n óo ṣe fọ́ àwọn eniyan yìí ati ìlú yìí, kò sì ní ní àtúnṣe mọ́. Ní Tofeti ni wọn yóo máa sin òkú sí nígbà tí wọn kò bá rí ààyè sin òkú sí mọ́.

12 Bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe sí ìlú yìí ati àwọn tí wọn ń gbé ibẹ̀. Bíi Tofeti ni n óo ṣe ìlú náà; Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

13 Àwọn ilé Jerusalẹmu ati àwọn ààfin ọba Juda, gbogbo ilé tí wọn ń sun turari sí àwọn ogun ọ̀run lórí òrùlé wọn, tí wọn sì ti rú ẹbọ ohun mímu sí àwọn oriṣa mìíràn, gbogbo wọn ni yóo di aláìmọ́ bíi Tofeti.”

14 Nígbà tí Jeremaya pada dé láti Tofeti, níbi tí OLUWA rán an lọ pé kí ó lọ sọ àsọtẹ́lẹ̀, ó dúró ní àgbàlá ilé OLUWA, ó sọ fún gbogbo àwọn tí wọ́n péjọ sibẹ pé,

15 “OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘N óo mú kí ibi tí mo ti kéde rẹ̀ dé bá ìlú yìí ati àwọn ìlú tí wọn yí i ká, nítorí wọ́n ti ṣe oríkunkun, wọn kò sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.’ ”

20

1 Nígbà tí Paṣuri alufaa, ọmọ Imeri, tí ó jẹ́ olórí àwọn olùṣọ́ ilé OLUWA, gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Jeremaya ń sọ,

2 ó ní kí wọn lu Jeremaya, kí wọn kàn ààbà mọ́ ọn lẹ́sẹ̀ ní ẹnu ọ̀nà Bẹnjamini ti òkè, ní ilé OLUWA.

3 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ keji, nígbà tí Paṣuri tú Jeremaya sílẹ̀ ninu ààbà, Jeremaya wí fún un pé, “Kì í ṣe Paṣuri ni OLUWA pe orúkọ rẹ, ìpayà lọ́tùn-ún ati lósì ni OLUWA pè ọ́.

4 OLUWA ní, ‘N óo sọ ọ́ di ìpayà fún ara rẹ ati fún gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn rẹ. Àwọn ọ̀tá yóo fi idà pa wọ́n níṣojú rẹ, n óo fi gbogbo ilẹ̀ Juda lé ọba Babiloni lọ́wọ́. Yóo kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí Babiloni, yóo sì fi idà pa wọ́n.

5 Bákan náà, n óo da gbogbo ọrọ̀ ìlú yìí, ati gbogbo èrè iṣẹ́ tí wọ́n ṣe lé àwọn ará Babiloni lọ́wọ́, pẹlu gbogbo nǹkan olówó iyebíye wọn, ati gbogbo ìṣúra àwọn ọba Juda; gbogbo rẹ̀ ni àwọn ọ̀tá wọn, àwọn ará Babiloni yóo fogun kó, wọn yóo sì rù wọ́n lọ sí Babiloni.

6 Ní ti ìwọ Paṣuri, ati gbogbo àwọn ará ilé rẹ, wọn óo ko yín ní ìgbèkùn lọ sí Babiloni. Ibẹ̀ ni ẹ óo kú sí, ibẹ̀ ni wọ́n óo sì sin yín sí; àtìwọ, ati gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ò ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.’ ”

7 OLUWA, o tàn mí jẹ, mo sì gba ẹ̀tàn; o ní agbára jù mí lọ, o sì borí mi. Mo di ẹni ẹ̀sín láti àárọ̀ títí di alẹ́, gbogbo eniyan ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́.

8 Gbogbo ìgbà tí mo bá ti sọ̀rọ̀, ni mò ń kígbe pé, “Ogun ati ìparun dé!” Nítorí náà, ọ̀rọ̀ OLUWA tí mò ń kéde sọ mí di ẹni yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru.

9 Ṣugbọn nígbàkúùgbà tí mo bá wí pé n kò ní dárúkọ rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ a máa jó mi ninu bí iná, a sì máa ro mí ninu egungun. Mo gbìyànjú títí pé kí n pa á mọ́ra, ṣugbọn kò ṣeéṣe.

10 Nítorí mò ń gbọ́ tí ọpọlọpọ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ pé, “Ìpayà wà lọ́tùn-ún lósì, ẹ lọ fẹjọ́ rẹ̀ sùn. Ẹ jẹ́ kí á fẹjọ́ rẹ̀ sùn.” Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń wí, tí wọn sì ń retí ìṣubú mi. Wọ́n ń sọ pé, “Bóyá yóo bọ́ sọ́wọ́ ẹlẹ́tàn, ọwọ́ wa yóo sì tẹ̀ ẹ́; a óo sì gbẹ̀san lára rẹ̀.”

11 Ṣugbọn OLUWA wà pẹlu mi bíi jagunjagun tí ó bani lẹ́rù. Nítorí náà àwọn tí wọn ń lépa mi yóo kọsẹ̀, apá wọn kò ní ká mi. Ojú yóo tì wọ́n lọpọlọpọ nítorí wọn kò ní lè borí mi. Ẹ̀sín tí ẹnikẹ́ni kò ní gbàgbé yóo dé bá wọn títí lae.

12 OLUWA àwọn ọmọ ogun, ìwọ tíí dán olódodo wò, ìwọ tí o mọ ọkàn ati èrò eniyan. Gbẹ̀san lára wọn kí n fojú rí i, nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.

13 Ẹ kọrin sí OLUWA, ẹ yin OLUWA. Nítorí pé ó gba ẹ̀mí aláìní sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn aṣebi.

14 Ègún ni fún ọjọ́ tí a bí mi, kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má jẹ́ ọjọ́ ayọ̀.

15 Ègún ni fún ẹni tí ó yọ̀ fún baba mi, tí ó sọ fún un pé, “Iyawo rẹ ti bí ọmọkunrin kan fún ọ, tí ó mú inú rẹ̀ dùn.”

16 Kí olúwarẹ̀ dàbí àwọn ìlú tí OLUWA parun láìṣàánú wọn. Kí ó gbọ́ igbe lówùúrọ̀, ati ariwo ìdágìrì lọ́sàn-án gangan.

17 Nítorí pé kò pa mí ninu oyún, kí inú ìyá mi lè jẹ́ isà òkú fún mi. Kí n wà ninu oyún ninu ìyá mi títí ayé.

18 Kí ló dé tí wọn bí mi sáyé? Ṣé kí n lè máa fojú rí ìṣẹ́ ati ìbànújẹ́ ni? Kí gbogbo ọjọ́ ayé mi lè kún fún ìtìjú?

21

1 Ọ̀rọ̀ tí Jeremaya gbọ́ lẹ́nu OLUWA nìyí nígbà tí ọba Sedekaya rán Paṣuri, ọmọ Malikaya, ati alufaa Sefanaya, ọmọ Maaseaya, sí i;

2 tí ọba Sedekaya ní, “Ẹ sọ fún Jeremaya pé kí ó bá wa ṣe ìwádìí lọ́dọ̀ OLUWA nípa Nebukadinesari, ọba Babiloni, tí ó gbógun tì wá; bóyá OLUWA yóo ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún wa, kí Nebukadinesari kó àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kúrò ní ilẹ̀ wa.”

3 Jeremaya sọ fun awọn tí wọn rán sí i,

4 kí wọ́n sọ fún Sedekaya pé OLUWA Ọlọrun Israẹli ní, “N óo gba àwọn ohun ìjà tí ó wà lọ́wọ́ yín, tí ẹ fi ń bá ọba Babiloni ati àwọn ará Kalidea tí wọn gbógun tì yín lẹ́yìn odi jà, n óo dá wọn pada sí ààrin ìlú, n óo sì dojú wọn kọ yín.

5 Èmi fúnra mi ni n óo ba yín jà. Ipá ati agbára, pẹlu ibinu ńlá, ati ìrúnú gbígbóná ni n óo fi ba yín jà.

6 N óo fi àjàkálẹ̀ àrùn ńlá kọlu àwọn ará ìlú yìí, ati eniyan ati ẹranko ni yóo sì kú.

7 Lẹ́yìn náà n óo mú Sedekaya ọba Juda, ati àwọn ìjòyè rẹ̀, ati àwọn tí àjàkálẹ̀ àrùn, ogun, ati ìyàn, bá pa kù ní ìlú yìí, n óo fi wọ́n lé Nebukadinesari, ọba Babiloni lọ́wọ́, òun ati àwọn ọ̀tá tí ń wá ọ̀nà láti pa wọ́n. Ọba Babiloni yóo fi idà pa wọ́n, kò ní ṣàánú wọn, kò sì ní dá ẹnikẹ́ni sí.”

8 OLUWA ní, “Sọ fún àwọn eniyan yìí pé èmi OLUWA ni mo la ọ̀nà meji níwájú wọn: ọ̀nà ìyè ati ọ̀nà ikú.

9 Ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn yóo pa ẹni tí ó bá dúró sinu ìlú yìí; ṣugbọn ẹni tí ó bá jáde tí ó sì fa ara rẹ̀ fún àwọn ará Kalidea, tí ó gbé ogun tì yín, yóo yè, yóo dàbí ẹni tó ja àjàbọ́.

10 Nítorí pé mo ti dójú lé ìlú yìí láti ṣe ní ibi, kì í ṣe fún rere. Ìlú yìí yóo bọ́ sọ́wọ́ ọba Babiloni, yóo sì dá iná sun ún, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11 OLUWA ní kí n sọ fún ìdílé ọba Juda pé òun OLUWA ní,

12 “Ẹ̀yin ará ilé Dafidi! Ẹ máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ ní òwúrọ̀, ẹ máa gba ẹni tí a jà lólè lọ́wọ́ aninilára, kí ibinu èmi OLUWA má baà ru jáde, nítorí iṣẹ́ ibi yín, kí ó sì máa jó bíi iná, láìsí ẹni tí yóo lè pa á.”

13 OLUWA ní, “Ẹ wò ó, mo dojú ìjà kọ yín, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé àfonífojì, tí ó dàbí àpáta tí ó yọ sókè ju pẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wí pé, ‘Ta ló lè dojú ìjà kọ wá? Àbí ta ló lè wọ inú odi ìlú wa?’

14 N óo jẹ yín níyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ yín; èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo dáná sun igbó yín, yóo sì jó gbogbo ohun tí ó wà ní agbègbè yín ní àjórun.”

22

1 OLUWA sọ fún mi pé, kí n lọ sí ilé ọba Juda kí n sọ fún un níbẹ̀ pé,

2 “Gbọ́ ohun tí OLUWA sọ, ìwọ ọba Juda, tí o jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, ìwọ ati àwọn ìjòyè rẹ ati àwọn eniyan rẹ, tí wọn ń gba àwọn ẹnubodè wọnyi wọlé:

3 Ẹ máa ṣe ẹ̀tọ́ ati òdodo, kí ẹ máa gba ẹni tí wọn ń jà lólè lọ́wọ́ àwọn aninilára. Ẹ má hùwà burúkú sí àwọn àlejò, tabi àwọn aláìníbaba, ati àwọn opó. Ẹ má ṣe wọ́n níbi, ẹ má sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibi mímọ́ yìí.

4 Nítorí pé bí ẹ bá fi tọkàntọkàn fetí sí ọ̀rọ̀ mi, àwọn ọba yóo máa wọlé, wọn yóo sì máa jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi. Wọn yóo máa gun ẹṣin ati kẹ̀kẹ́ ogun àtàwọn, ati àwọn ìjòyè wọn, ati àwọn eniyan.

5 Ṣugbọn bí ẹ kò bá gba ohun tí mo wí, mo ti fi ara mi búra pé ilẹ̀ yìí yóo di ahoro. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

6 OLUWA sọ nípa ìdílé ọba Juda pé, “Bíi Gileadi ni o dára lójú mi, ati bí orí òkè Lẹbanoni. Ṣugbọn sibẹ, dájúdájú, n óo sọ ọ́ di aṣálẹ̀; o óo sì di ìlú tí ẹnikẹ́ni kò ní gbé.

7 N óo kó àwọn apanirun tí yóo pa ọ́ run wá, olukuluku yóo wá pẹlu ohun ìjà rẹ̀. Wọn óo gé àwọn tí wọn dára jùlọ ninu àwọn igi Kedari yín, wọn óo sì sun wọ́n níná.

8 “Ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè ni yóo máa gba ìlú yìí kọjá; wọn yóo sì máa bi ara wọn pé, ‘Kí ló dé tí OLUWA fi ṣe báyìí sí ìlú ńlá yìí?’

9 Àwọn eniyan yóo sì máa dáhùn pé, ‘Nítorí pé wọ́n kọ majẹmu OLUWA Ọlọrun wọn sílẹ̀ ni, wọ́n ń bọ oriṣa, wọ́n sì ń sìn wọ́n.’ ”

10 Ẹ̀yin ará Juda, ẹ má sọkún nítorí ọba tí ó kú, ẹ má sì dárò rẹ̀. Ọba tí ń lọ sí ìgbèkùn ni kí ẹ sọkún fún, nítorí pé yóo lọ, kò sì ní pada wá mọ́ láti fojú kan ilẹ̀ tí a bí i sí.

11 Nítorí pé OLUWA sọ nípa Joahasi, ọba Juda, ọmọ Josaya, tí ó jọba dípò Josaya baba rẹ̀, tí ó sì jáde kúrò ní ibí yìí pé, “Kò ní pada sibẹ mọ́.

12 Ibi tí wọn mú un ní ìgbèkùn lọ ni yóo kú sí; kò ní fi ojú rí ilẹ̀ yìí mọ́.”

13 Ẹni tí ó ń fi aiṣododo kọ́ ilé rẹ̀ gbé, tí ó ń fi ọ̀nà èrú kọ́ òrùlé rẹ̀. Tí ó mú ọmọ ẹnìkejì rẹ̀ sìn lọ́fẹ̀ẹ́, láìsan owó iṣẹ́ rẹ̀ fún un.

14 Ègbé ni fún ẹni tí ó wí pé, “N óo kọ́ ilé ńlá fún ara mi, ilé tí ó ní yàrá ńláńlá lókè rẹ̀.” Ó bá yọ àwọn fèrèsé sí i lẹ́gbẹ̀ẹ́. Ó fi igi kedari bo ara ògiri rẹ̀, ó wá fi ọ̀dà pupa kùn ún.

15 Ṣé ilé kedari tí o kọ́ ni ó sọ ọ́ di ọba? Wo baba rẹ, ṣé kò rí jẹ ni, tabi kò rí mu? Ṣebí ó ṣe ẹ̀tọ́ ati òdodo, ṣebí ó sì dára fún un.

16 Ẹjọ́ ẹ̀tọ́ níí dá fún talaka ati aláìní, ohun gbogbo sì ń lọ dáradára. Ṣebí èyí ni à ń pè ní kí eniyan mọ OLUWA? OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

17 Ṣugbọn níbi èrè aiṣododo nìkan ni ojú ati ọkàn yín ń wà, níbi kí ẹ máa pa aláìṣẹ̀, kí ẹ máa ni eniyan lára, kí ẹ sì máa hùwà ìkà.

18 Nítorí náà, OLUWA sọ nípa Jehoiakimu, ọba Juda, ọmọ Josaya pé, wọn kò ní dárò rẹ̀, pé, “Ó ṣe, arakunrin mi!” Tabi pé, “Ó ṣe, arabinrin mi!” Wọn kò ní ké pé, “Ó ṣe, oluwa mi!” Tabi pé, “Ó ṣe! Áà! Kabiyesi!”

19 Bí ẹni ń ṣe òkú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni wọ́n óo ṣe òkú rẹ̀; ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ni wọn yóo wọ́ ọ jù sí. Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu,

20 ẹ gun orí òkè Lẹbanoni lọ, kí ẹ kígbe. Ẹ dúró lórí òkè Baṣani, kí ẹ pariwo gidigidi, ẹ kígbe láti orí òkè Abarimu, nítorí pé a ti pa gbogbo àwọn alájọṣe yín run.

21 OLUWA bá yín sọ̀rọ̀ nígbà tí nǹkan ń dára fun yín, ṣugbọn ẹ sọ pé ẹ kò ní gbọ́. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ tí ń ṣe láti kékeré yín, ẹ kì í gbọ́rọ̀ sí OLUWA lẹ́nu.

22 Afẹ́fẹ́ yóo fẹ́ gbogbo àwọn olórí yín lọ, àwọn olólùfẹ́ yín yóo lọ sí ìgbèkùn. Ojú yóo wá tì yín, ẹ óo sì di ẹni ẹ̀tẹ́, nítorí gbogbo ibi tí ẹ̀ ń ṣe.

23 Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé Lẹbanoni, tí ẹ kọ́ ilé yín sí ààrin igi kedari. Ẹ óo kérora nígbà tí ara bá ń ni yín, tí ara ń ni yín bíi ti obinrin tí ń rọbí ọmọ!

24 OLUWA sọ fún Jehoiakini ọba, ọmọ Jehoiakimu, ọba Juda, pé, “Mo fi ara mi búra, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Bí ó bá tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ ni òrùka èdìdì ọwọ́ ọ̀tún mi,

25 n óo bọ́ ọ kúrò, n óo sì fi ọ́ lé Nebukadinesari ọba Babiloni, ati àwọn ará Kalidea lọ́wọ́, àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí rẹ, tí ẹ̀rù wọn sì ń bà ọ́.

26 N óo wọ́ ìwọ ati ìyá tí ó bí ọ jù sí ilẹ̀ àjèjì, tí kì í ṣe ibi tí wọ́n bí ọ sí, ibẹ̀ ni ẹ óo kú sí.

27 Ṣugbọn ilẹ̀ tí ọkàn yín fẹ́ pada sí, ẹ kò ní pada sibẹ mọ́.”

28 Ṣé àfọ́kù ìkòkò tí ẹnikẹ́ni kò kà kún ni Jehoiakini? Àbí o ti di ohun èlò àlòpatì? Kí ló dé tí òun ati àwọn ọmọ rẹ̀ fi di ẹni tí a kó lẹ́rú lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀ rí?

29 Ilẹ̀! Ilẹ̀! Gbọ́ ohun tí OLUWA sọ!

30 Ó ní, “Ẹ kọ orúkọ ọkunrin yìí sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kò ní ṣe rere kan ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí pé kò sí ọ̀kankan ninu àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóo rọ́pò rẹ̀ lórí ìtẹ́ Dafidi, Ìdílé rẹ̀ kò sì ní jọba mọ ní Juda.”

23

1 OLUWA ní, “Àwọn olùṣọ́-aguntan tí wọn ń tú àwọn agbo aguntan mi ká, tí wọn ń run wọ́n gbé!”

2 Nítorí náà, OLUWA, Ọlọrun Israẹli sọ nípa àwọn tí ó fi ṣọ́ àwọn eniyan rẹ̀, láti máa bojútó wọn pé, “Ẹ ti tú àwọn aguntan mi ká, ẹ ti lé wọn dànù, ẹ kò sì tọ́jú wọn. N óo wá ṣe ìdájọ́ fun yín nítorí iṣẹ́ ibi yín, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

3 N óo kó àwọn tí wọ́n kù ninu àwọn aguntan mi jọ láti gbogbo ibi tí mo lé wọn lọ. N óo kó wọn pada sinu agbo wọn. Wọn óo bímọ lémọ, wọn óo sì máa pọ̀ sí i.

4 N óo wá fún wọn ní olùṣọ́ mìíràn tí yóo tọ́jú wọn. Ẹ̀rù kò ní bà wọ́n mọ́, wọn kò ní fòyà, ọ̀kankan ninu wọn kò sì ní sọnù, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

5 “Wò ó! Àkókò kan ń bọ̀, tí n óo gbé Ẹ̀ka olódodo kan dìde ninu ìdílé Dafidi. Yóo jọba, yóo hùwà ọlọ́gbọ́n, yóo sì ṣe ẹ̀tọ́ ati òdodo ní ilẹ̀ náà.

6 Juda yóo rí ìgbàlà ní ìgbà tirẹ̀, Israẹli yóo sì wà láìléwu. Orúkọ tí a óo máa pè é ni ‘OLUWA ni òdodo wa.’

7 “Nítorí náà àkókò kan ń bọ̀, tí wọn kò ní máa búra ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti mọ́,

8 ṣugbọn tí wọn yóo máa wí pé, ‘Ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ ilé Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá, ati gbogbo ilẹ̀ tí wọn kó wọn lẹ́rú lọ, tí ó sì mú wọn pada sí ilẹ̀ wọn.’ Wọn óo wá máa gbé orí ilẹ̀ wọn nígbà náà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

9 Ọkàn mi bàjẹ́ nítorí àwọn wolii, gbogbo ara mi ń gbọ̀n. Mo dàbí ọ̀mùtí tí ó ti mu ọtí yó, mo dàbí ẹni tí ọtí ń pa, nítorí OLUWA, ati nítorí ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.

10 Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún àgbèrè ẹ̀sìn, ọ̀nà ibi ni wọ́n ń tọ̀, wọn kò sì lo agbára wọn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ nítorí ègún, ilẹ̀ ti di gbígbẹ gbogbo pápá oko ló ti gbẹ.

11 Ati wolii, ati alufaa, ìwà burúkú ni wọ́n ń hù, ní ilé mi pàápàá mo rí iṣẹ́ ibi wọn, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

12 Nítorí náà ọ̀nà wọn yóo dàbí ọ̀nà tí ń yọ̀ ninu òkùnkùn, a óo tì wọ́n sinu rẹ̀, wọn yóo sì ṣubú, nítorí n óo mú kí ibi bá wọn ní ọdún ìjìyà wọn.

13 Mo rí nǹkankan tí ó burú lọ́wọ́ àwọn wolii Samaria: Ẹ̀mí oriṣa Baali ni wọ́n fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀; wọ́n sì ń ṣi àwọn ọmọ Israẹli, eniyan mi, lọ́nà.

14 Mo rí nǹkankan tí ó bani lẹ́rù lọ́wọ́ àwọn wolii Jerusalẹmu: Wọ́n ń ṣe àgbèrè ẹ̀sìn, wọ́n ń hùwà èké; wọ́n ń ran àwọn ẹni ibi lọ́wọ́, kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni yipada kúrò ninu iṣẹ́ ibi rẹ̀. Gbogbo wọn ti di ará Sodomu lójú mi, àwọn ará Jerusalẹmu sì dàbí àwọn ará Gomora.

15 Nítorí náà OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa àwọn wolii pé: N óo fún wọn ní ewé igi kíkorò jẹ, n óo fún wọn ní omi májèlé mu. Nítorí pé láti ọ̀dọ̀ àwọn wolii Jerusalẹmu ni ìwà burúkú ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ yìí.

16 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wolii tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fun yín, tí wọ́n ń mu yín gbẹ́kẹ̀lé irọ́. Ohun tí wọn fẹ́ lọ́kàn wọn ni wọ́n ń sọ, kì í ṣe ẹnu èmi OLUWA ni wọ́n ti gbọ́ ọ.

17 Wọ́n ń sọ lemọ́lemọ́ fún àwọn tí wọn kò ka ọ̀rọ̀ OLUWA sí pé, yóo dára fún wọn. Wọ́n ń wí fún gbogbo àwọn tí wọn ń tẹ̀lé àìgbọràn ọkàn wọn pé ibi kò ní bá wọn.”

18 Mo ní, “Èwo ninu wọn ló wà ninu ìgbìmọ̀ OLUWA tí ó ti ṣe akiyesi tí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Èwo ninu wọn ni ó fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó sì gbà á gbọ́?

19 Ẹ wo ibinu OLUWA bí ó ṣe ń jà bí ìjì! Ó ti fa ibinu yọ. Ó sì ń jà bí ìjì líle. Yóo tú dà sí orí àwọn eniyan burúkú.

20 Inú OLUWA kò ní rọ̀ títí yóo fi ṣe ohun tí ó pinnu lọ́kàn rẹ̀. Yóo ye wọn nígbà tí ọjọ́ ìkẹyìn bá dé.”

21 OLUWA ní, “N kò rán àwọn wolii níṣẹ́, sibẹsibẹ aré ni wọ́n ń sá lọ jíṣẹ́. N kò bá wọn sọ̀rọ̀, sibẹsibẹ wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀.

22 Bí wọn bá ti bá mi pé ní ìgbìmọ̀ ni, wọn ìbá kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn eniyan mi, wọn ìbá yí wọn pada kúrò lọ́nà ibi tí wọn ń rìn, ati iṣẹ́ ibi tí wọn ń ṣe.

23 “Ṣé nítòsí nìkan ni mo ti jẹ́ Ọlọrun ni, èmi kì í ṣe Ọlọrun ọ̀nà jíjìn?

24 Ǹjẹ́ ẹnìkan lè sápamọ́ sí ìkọ̀kọ̀ kan tí n kò fi ní rí i? Kì í ṣe èmi ni mo wà ní gbogbo ọ̀run tí mo sì tún wà ní gbogbo ayé?

25 Mo gbọ́ ohun tí àwọn wolii tí wọn ń fi orúkọ mi sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ń sọ, tí wọn ń sọ pé, àwọn lá àlá, àwọn lá àlá!

26 Irọ́ yóo ti pẹ́ tó lọ́kàn àwọn wolii èké tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.

27 Wọ́n ṣebí àwọn lè fi àlá tí olukuluku wọn ń rọ́ fún ẹnìkejì rẹ̀ mú àwọn eniyan mi gbàgbé orúkọ mi, bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé mi, tí wọn ń tẹ̀lé oriṣa Baali.

28 Kí àwọn wolii tí wọn lá àlá máa rọ́ àlá wọn, ṣugbọn ẹni tí ó bá gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ó sọ ọ́ pẹlu òtítọ́. Báwo ni a ṣe lè fi ìyàngbò wé ọkà?

29 Ṣebí bí iná ni ọ̀rọ̀ mi rí, ati bí òòlù irin tíí fọ́ àpáta sí wẹ́wẹ́?

30 Nítorí náà, mo dojú ìjà kọ àwọn wolii tí wọn ń sọ ọ̀rọ̀ tí wọn gbọ́ lẹ́nu ara wọn, tí wọn ń sọ pé èmi ni mo sọ ọ́.

31 Mo lòdì sí àwọn wolii tí wọn ń sọ ọ̀rọ̀ ti ara wọn, tí wọn ń sọ pé èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

32 Mo lòdì sí àwọn wolii tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlá irọ́, tí wọn ń rọ́ àlá irọ́ wọn, tí wọn fí ń ṣi àwọn eniyan mi lọ́nà pẹlu irọ́ ati ìṣekúṣe wọn, nígbà tí n kò rán wọn níṣẹ́, tí n kò sì fún wọn láṣẹ. Nítorí náà wọn kò ṣe àwọn eniyan wọnyi ní anfaani kankan. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

33 Bí ọ̀kan ninu àwọn eniyan wọnyi, tabi wolii kan, tabi alufaa kan, bá bi ọ́ léèrè pé, “Kí ni iṣẹ́ tí OLUWA rán?” Wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin gan-an ni ẹ jẹ́ ẹrù. OLUWA sì ní òun óo gbé yín sọnù.”

34 Bí wolii kan tabi alufaa kan tabi ẹnikẹ́ni ninu àwọn eniyan wọnyi bá wí pé òun ń jẹ́ iṣẹ́ OLUWA, n óo jẹ olúwarẹ̀ ati ilé rẹ̀ níyà.

35 Báyìí ni kí ẹnìkọ̀ọ̀kan máa wí fún ẹnìkejì rẹ, ati fún arakunrin rẹ̀, “Kí ni ìdáhùn OLUWA?” tabi “Kí ni OLUWA wí?”

36 Ṣugbọn ẹ kò gbọdọ̀ mẹ́nuba ẹrù OLUWA mọ́. Nítorí pé èrò ọkàn olukuluku ni ẹrù OLUWA lójú ara rẹ̀; ẹ sì ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọrun alààyè po, ọ̀rọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun wa.

37 Bí ẹ óo ti máa bèèrè lọ́wọ́ àwọn wolii ni pé, “Kí ni ìdáhùn tí OLUWA fún ọ?” Tabi, “Kí ni OLUWA wí?”

38 Ṣugbọn bí ẹ bá mẹ́nu ba “Ẹrù OLUWA,” lẹ́yìn tí mo ti ranṣẹ si yín pé ẹ kò gbọdọ̀ mẹ́nu bà á mọ́,

39 tìtorí rẹ̀, n óo sọ yín sókè, n óo sì gbe yín sọnù kúrò níwájú mi, àtẹ̀yin, àtìlú tí mo fi fún ẹ̀yin, ati àwọn baba ńlá yín.

40 N óo mú ẹ̀gàn ati ẹ̀sín ba yín, tí ẹ kò ní gbàgbé títí ayérayé.

24

1 Lẹ́yìn tí Nebukadinesari, ọba Babiloni ti kó Jehoiakini ọba Juda, ọmọ Jehoiakimu kúrò ní ìlú Jerusalẹmu lọ sí Babiloni, pẹlu àwọn ìjòyè Juda, ati àwọn oníṣẹ́ ọnà, ati àwọn alágbẹ̀dẹ, OLUWA fi ìran yìí hàn mí. Mo rí apẹ̀rẹ̀ èso ọ̀pọ̀tọ́ meji níwájú ilé OLUWA.

2 Èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó wà ninu apẹ̀rẹ̀ kinni dára gbáà, ó dàbí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó kọ́kọ́ pọ́n. Èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó wà ninu apẹ̀rẹ̀ keji ti rà patapata tóbẹ́ẹ̀ tí kò ṣe é jẹ. p

3 OLUWA bá bi mí pé, “Jeremaya, kí ni o rí?” Mo ní, “Èso ọ̀pọ̀tọ́ ni, àwọn tí ó dára, dára gan-an, àwọn tí kò sì dára bàjẹ́ tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò ṣe é jẹ.”

4 OLUWA tún bá mi sọ̀rọ̀, ó ní,

5 “Ohun tí èmi OLUWA Ọlọrun Israẹli sọ nípa àwọn ará Juda tí wọ́n wà ní ìgbèkùn, àwọn tí mo ti mú kí á kó lẹ́rú láti ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kalidea, ni pé, n óo kà wọ́n sí rere gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára wọnyi.

6 N óo fi ojurere wò wọ́n, n óo kó wọn pada wá sí ilẹ̀ yìí. N óo fìdí wọn múlẹ̀, n kò sì ní pa wọ́n run. N óo gbé wọn ró, n kò ní fà wọ́n tu,

7 n óo sì fún wọn ní òye láti mọ̀ pé èmi ni OLUWA. Wọn yóo jẹ́ eniyan mi, èmi náà óo sì jẹ́ Ọlọrun wọn; nítorí tí wọn yóo fi tọkàntọkàn yipada sí mi.”

8 Ṣugbọn ohun tí OLUWA sọ nípa Sedekaya ọba Juda, ati àwọn ìjòyè rẹ̀, ati àwọn ará Jerusalẹmu tí wọ́n kù ní ilẹ̀ yìí, ati àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ Ijipti, ni pé òun óo ṣe wọ́n bí èso burúkú tí kò ṣe é jẹ.

9 Ó ní òun óo sọ wọ́n di ẹni àríbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba ayé. Wọn óo di ẹni ẹ̀gàn, ẹni ẹ̀sín, ẹni yẹ̀yẹ́ ati ẹni tí a fi ń ṣẹ́ èpè ní gbogbo ibi tí òun óo tì wọ́n lọ.

10 Ó ní òun óo rán ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn sí wọn, títí wọn yóo fi kú tán, tí kò ní ku ẹyọ ẹnìkan lórí ilẹ̀ tí òun fún àwọn ati àwọn baba ńlá wọn.

25

1 Ní ọdún kẹrin tí Jehoiakimu, ọmọ Josaya jọba ní Juda, tí ó jẹ́ ọdún kinni tí Nebukadinesari jọba Babiloni, Jeremaya wolii gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA nípa gbogbo àwọn ará Juda.

2 Jeremaya sọ ọ̀rọ̀ náà fún gbogbo àwọn ará Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu.

3 Ó ní, “Fún ọdún mẹtalelogun, láti ọdún kẹtala tí Josaya ọmọ Amoni ti jọba Juda, títí di ọjọ́ òní, ni OLUWA ti ń bá mi sọ̀rọ̀, tí mo sì ti ń sọ ọ́ fun yín lemọ́lemọ́, ṣugbọn tí ẹ kò sì gbọ́.

4 Ẹ kò fetí sílẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nígbà gbogbo ni OLUWA ń rán àwọn wolii, iranṣẹ rẹ̀, si yín, tí wọn ń sọ fun yín pé

5 kí olukuluku yín yipada kúrò ní ọ̀nà burúkú rẹ̀ ati iṣẹ́ ibi tí ó ń ṣe, kí ẹ lè máa gbé ilẹ̀ tí OLUWA fún ẹ̀yin ati àwọn baba ńlá yín títí lae, láti ìgbà àtijọ́.

6 Wọ́n ní kí ẹ má wá àwọn oriṣa lọ, kí ẹ má bọ wọ́n, kí ẹ má sì sìn wọ́n. Wọ́n ní kí ẹ má fi iṣẹ́ ọwọ́ yín mú un bínú, kí ó má baà ṣe yín ní ibi.”

7 OLUWA alára ní, “Mo wí, ṣugbọn ẹ kò gbọ́ tèmi; kí ẹ lè fi iṣẹ́ ọwọ́ yín mú mi bínú, fún ìpalára ara yín.”

8 Ó ní, “Nítorí pé ẹ kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu,

9 n óo ranṣẹ lọ kó gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè àríwá wá. N óo ranṣẹ sí Nebukadinesari ọba Babiloni, iranṣẹ mi, n óo jẹ́ kí wọn wá dó ti ilẹ̀ yìí, ati àwọn tí ń gbé ibẹ̀. Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ yìí ni n óo parun patapata, tí n óo sọ di àríbẹ̀rù, ati àrípòṣé, ati ohun ẹ̀gàn títí lae.

10 N óo pa ìró ayọ̀ ati ẹ̀rín rẹ́ láàrin wọn, ẹnìkan kò sì ní gbọ́ ohùn ọkọ iyawo ati ohùn iyawo tuntun mọ́. A kò ní gbọ́ ìró ọlọ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò ní sí iná fìtílà mọ́.

11 Gbogbo ilẹ̀ yìí yóo di àlàpà ati aṣálẹ̀. Àwọn orílẹ̀-èdè wọnyi yóo sì sin ọba Babiloni fún aadọrin ọdún.

12 Nígbà tí aadọrin ọdún bá pé, n óo jẹ ọba Babiloni ati orílẹ̀-èdè rẹ̀, ati ilẹ̀ àwọn ará Kalidea níyà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. N óo sì sọ ibẹ̀ di àlàpà títí ayé.

13 N óo mú gbogbo ọ̀rọ̀ burúkú tí mo ti sọ nípa ilẹ̀ náà ṣẹ, ati gbogbo ohun tí a kọ sinu ìwé yìí, àní àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tí Jeremaya sọ nípa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.

14 Ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè ati àwọn ọba alágbára yóo sọ àwọn ará Babiloni pàápàá di ẹrú, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀san ìṣe wọn ati iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”

15 OLUWA Ọlọrun Israẹli sọ fún mi pé, “Gba ife ọtí ibinu yìí lọ́wọ́ mi, kí o fún gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí n óo rán ọ sí mu.

16 Wọn yóo mu ún, wọn yóo sì máa ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n, wọn yóo máa ṣe bí aṣiwèrè nítorí ogun tí n óo rán sí ààrin wọn.”

17 Mo bá gba ife náà lọ́wọ́ OLUWA, mo sì fún gbogbo orílẹ̀-èdè tí OLUWA rán mi sí mu:

18 Jerusalẹmu ati àwọn ìlú Juda, àwọn ọba ilẹ̀ Juda ati àwọn ìjòyè wọn, kí wọn lè di ahoro ati òkítì àlàpà, nǹkan àrípòṣé ati ohun tí à ń fi í ṣépè, bí ó ti rí ní òní yìí.

19 N óo fún Farao, ọba Ijipti mu, ati àwọn iranṣẹ rẹ̀ ati àwọn ìjòyè rẹ̀, ati gbogbo àwọn eniyan rẹ̀

20 ati àwọn àlejò tí wọ́n wà láàrin wọn. N óo fún gbogbo àwọn ọba Usi mu, ati gbogbo àwọn ọba ilẹ̀ Filistini, (Aṣikeloni, Gasa, Ekironi ati àwọn tí wọ́n kù ní Aṣidodu).

21 N óo fún Edomu mu, ati Moabu, ati àwọn ọmọ Amoni;

22 ati gbogbo àwọn ọba Tire, ati àwọn ọba Sidoni, ati gbogbo àwọn ọba erékùṣù tí ó wà ní òdìkejì òkun.

23 N óo fún Dedani mu, ati Tema, ati Busi ati gbogbo àwọn tí wọn ń gé ẹsẹ̀ irun wọn.

24 N óo fún gbogbo àwọn ọba Arabia mu ati gbogbo àwọn ọba oríṣìíríṣìí ẹ̀yà tí wọn ń gbé aṣálẹ̀.

25 N óo fún gbogbo àwọn ọba ilẹ̀ Simiri mu, ati gbogbo àwọn ọba ilẹ̀ Elamu ati gbogbo àwọn ti ilẹ̀ Media;

26 ati gbogbo àwọn ọba ilẹ̀ àríwá, ati àwọn tí wọ́n wà nítòsí, ati àwọn tí wọ́n wà lọ́nà jíjìn. N óo sì fún àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ ayé mu pẹlu. Lẹ́yìn tí gbogbo wọn bá ti mu tiwọn tán, ọba Babiloni yóo wá mu tirẹ̀.

27 OLUWA ní kí n sọ fún wọn pé, “OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní kí ẹ mu ọtí kí ẹ yó, kí ẹ sì máa bì, ẹ ṣubú lulẹ̀ kí ẹ má dìde mọ́; nítorí ogun tí n óo jẹ́ kí ó bẹ́ sílẹ̀ ní ààrin yín.

28 Bí wọn bá kọ̀ tí wọn kò gba ife náà lọ́wọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, wí fún wọn pé, OLUWA àwọn ọmọ ogun ní wọ́n gbọdọ̀ mu ún ni!

29 Nítorí pé mo ti bẹ̀rẹ̀ sí mú kí ibi ṣẹlẹ̀ sórí ìlú tí à ń fi orúkọ mi pè yìí, ǹjẹ́ ẹ lè lọ láìjìyà bí? Rárá o, ẹ kò ní lọ láìjìyà nítorí pé mo ti pàṣẹ pé kí gbogbo àwọn tí wọn ń gbé orí ilẹ̀ ayé kú ikú idà, èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

30 “Nítorí náà, sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí fún wọn pé: ‘OLUWA yóo bú ramúramù láti òkè, yóo pariwo láti ibi mímọ́ rẹ̀. Yóo bú ramúramù mọ́ àwọn eniyan inú agbo rẹ̀. Yóo kígbe mọ́ gbogbo aráyé bí igbe àwọn tí ń tẹ àjàrà.

31 Ariwo náà yóo kàn dé òpin ayé, nítorí pé OLUWA ní ẹjọ́ láti bá àwọn orílẹ̀-èdè rò. Yóo dá gbogbo eniyan lẹ́jọ́, yóo fi idà pa àwọn eniyan burúkú, OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.’ ”

32 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ibi yóo máa ṣẹlẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan dé ekeji, ìjì ńlá yóo sì jà láti òpin ayé wá.

33 Òkú àwọn tí OLUWA yóo pa ní ọjọ́ náà yóo kún inú ayé láti òpin kan dé ekeji. Ẹnikẹ́ni kò ní ṣọ̀fọ̀ wọn, kò sí ẹni tí yóo gbé òkú wọn nílẹ̀; wọn kò ní sin wọ́n. Wọn yóo dàbí ìgbẹ́ lórí ilẹ̀.

34 Ẹ̀yin olùṣọ́-aguntan, ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ kígbe. Ẹ̀yin oluwa àwọn agbo ẹran, ẹ máa yíra mọ́lẹ̀ ninu eérú nítorí àkókò tí a óo pa yín, tí a óo sì tu yín ká ti tó, ẹ óo sì ṣubú lulẹ̀ bí ẹran àbọ́pa.

35 Kò ní sí ààbò mọ́ fún àwọn olùṣọ́-aguntan, kò ní sí ọ̀nà ati sá àsálà fún àwọn oluwa àwọn agbo ẹran.

36 Ẹ gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-aguntan ati ẹkún ẹ̀dùn ti àwọn oluwa agbo ẹran; nítorí OLUWA ń ba ibùjẹ ẹran wọn jẹ́.

37 Pápá oko tútù tí ìbẹ̀rù kò sí níbẹ̀ tẹ́lẹ̀ ti di ahoro nítorí ibinu gbígbóná OLUWA.

38 Bíi kinniun tí ó fi ihò rẹ̀ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA fi àwọn eniyan rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn sì ti di ahoro nítorí idà apanirun ati ibinu gbígbóná OLUWA.

26

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Jehoiakimu ọba Juda, ọmọ Josaya,

2 OLUWA bá mi sọ̀rọ̀; ó ní, “Dúró sí gbọ̀ngàn ilé OLUWA, kí o sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo pa láṣẹ fún ọ pé kí o sọ fún gbogbo àwọn ará ìlú Juda tí wọn ń wá jọ́sìn níbẹ̀. Má fi ọ̀rọ̀ kankan pamọ́.

3 Ó ṣeéṣe kí wọ́n gbọ́, kí olukuluku wọn sì yipada kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀; kí n lè yí ọkàn mi pada nípa ibi tí mo fẹ́ ṣe sí wọn nítorí iṣẹ́ burúkú wọn.

4 “Sọ fún wọn pé, èmi OLUWA ní bí wọn kò bá fetí sí ọ̀rọ̀ mi, kí wọn máa pa òfin tí mo gbé kalẹ̀ fún wọn mọ́,

5 kí wọn sì máa gbọ́ràn sí àwọn iranṣẹ mi lẹ́nu, ati àwọn wolii mi tí mò ń rán sí wọn léraléra, bí wọn kò tilẹ̀ kà wọ́n sí,

6 nítorí náà ni n óo ṣe ṣe ilé yìí bí mo ti ṣe Ṣilo; n óo sì sọ ìlú yìí di ohun tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé yóo máa fi gégùn-ún.”

7 Àwọn alufaa, àwọn wolii ati gbogbo àwọn eniyan gbọ́ tí Jeremaya ń sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ilé OLUWA.

8 Nígbà tí ó sọ gbogbo ohun tí OLUWA pa láṣẹ fún un pé kí ó sọ fún gbogbo àwọn eniyan náà tán, gbogbo wọn rá a mú, wọ́n ní, “Kíkú ni o óo kú!

9 Kí ló dé tí o fi sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ OLUWA pé ‘Ilé yìí yóo dàbí Ṣilo, ati pé ìlú yìí yóo di ahoro, ẹnikẹ́ni kò sì ní gbébẹ̀ mọ́?’ ” Gbogbo eniyan bá pé lé Jeremaya lórí ninu ilé OLUWA.

10 Nígbà tí àwọn ìjòyè Juda gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, wọ́n lọ sí ilé OLUWA láti ààfin ọba, wọ́n sì jókòó ní Ẹnu Ọ̀nà Titun tí ó wà ní ilé OLUWA.

11 Àwọn alufaa ati àwọn wolii bá sọ fún àwọn ìjòyè ati gbogbo àwọn eniyan pé, “Ẹjọ́ ikú ni ó yẹ kí a dá fún ọkunrin yìí nítorí àsọtẹ́lẹ̀ tí ó ń sọ nípa ìlú yìí, ẹ̀yin náà sá fi etí ara yín gbọ́.”

12 Jeremaya bá sọ fún àwọn ìjòyè ati gbogbo àwọn eniyan pé, “OLUWA ni ó rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ tí ẹ gbọ́ sí ilé yìí ati ìlú yìí.

13 Nítorí náà, ẹ tún ọ̀nà yín ṣe, ẹ pa ìṣe yín dà, kí ẹ sì gbọ́ràn sí OLUWA Ọlọrun yín lẹ́nu, yóo sì yí ọkàn rẹ̀ pada kúrò ninu ibi tí ó sọ pé òun yóo ṣe sí i yín.

14 Ní tèmi, mo wà lọ́wọ́ yín, ohun tí ó bá dára lójú yín ni kí ẹ fi mí ṣe.

15 Ṣugbọn kí ẹ mọ̀ dájú pé bí ẹ bá pa mí, ẹ óo fa ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sórí ara yín, ati ìlú yìí ati àwọn ará ìlú yìí, nítorí pé nítòótọ́ ni OLUWA rán mi pé kí n sọ gbogbo ohun tí mo sọ kí ẹ gbọ́.”

16 Àwọn ìjòyè ati gbogbo àwọn eniyan bá sọ fún àwọn alufaa ati àwọn wolii pé, “Ẹjọ́ ikú kò tọ́ sí ọkunrin yìí, nítorí pé orúkọ OLUWA Ọlọrun wa ni ó fi ń bá wa sọ̀rọ̀.”

17 Àwọn kan ninu àwọn àgbààgbà ìlú dìde, wọ́n bá gbogbo ìjọ eniyan sọ̀rọ̀; wọ́n ní,

18 “Ní ìgbà Hesekaya ọba Juda, Mika ará Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún gbogbo àwọn ará Juda pé OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, ‘A óo kọ Sioni bí ilẹ̀ oko, Jerusalẹmu yóo di òkítì àlàpà; òkè ilé yìí yóo sì di igbó kìjikìji.’

19 Ǹjẹ́ Hesekaya ati gbogbo eniyan Juda pa Mika bí? Ṣebí OLUWA yí ibi tí ó ti pinnu láti ṣe sí wọn pada, nítorí pé Hesekaya bẹ̀rù OLUWA ó sì wá ojurere rẹ̀. Ṣugbọn ní tiwa ibi ńláńlá ni a fẹ́ fà lé orí ara wa yìí.”

20 Ọkunrin kan tún wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Uraya, ọmọ Ṣemaaya, láti ìlú Kiriati Jearimu. Òun náà sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ yìí ati ilẹ̀ wa bí Jeremaya ti sọ yìí.

21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu ati àwọn ọmọ ogun rẹ̀, ati àwọn ìjòyè gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba wá ọ̀nà láti pa á. Nígbà tí Uraya gbọ́, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí ilẹ̀ Ijipti.

22 Ṣugbọn ọba Jehoiakimu rán Elinatani, ọmọ Akibori, ati àwọn ọkunrin kan lọ sí Ijipti,

23 wọ́n mú Uraya jáde ní ilẹ̀ Ijipti, wọ́n mú un tọ ọba Jehoiakimu wá. Ọba Jehoiakimu fi idà pa á, ó sì ju òkú rẹ̀ sí ibi tí wọn ń sin àwọn talaka sí.

24 Ṣugbọn Ahikamu ọmọ Ṣafani fọwọ́ sí ọ̀rọ̀ mi, kò sì jẹ́ kí á fà mí lé àwọn eniyan lọ́wọ́ láti pa.

27

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekaya, ọba Juda, ọmọ Josaya, OLUWA bá èmi Jeremaya sọ̀rọ̀; ó ní:

2 “Ṣe àjàgà kan pẹlu okùn rẹ̀ kí o sì fi bọ ara rẹ lọ́rùn.

3 Àwọn ikọ̀ kan wá sí ọ̀dọ̀ Sedekaya, ọba Juda, ní Jerusalẹmu, láti ọ̀dọ̀ ọba Edomu ati ọba Moabu, ọba àwọn ọmọ Amoni, ọba Tire, ati ọba Sidoni wá, rán wọn pada sí àwọn oluwa wọn,

4 sì pàṣẹ fún wọn pé kí wọ́n sọ fún wọn pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní

5 òun ni òun fi agbára ńlá òun dá ayé: ati eniyan ati ẹranko tí wọ́n wà lórí ilẹ̀; ẹni tí ó bá tọ́ lójú òun ni òun óo sì fi wọ́n fún.

6 Ó ní òun ti fún Nebukadinesari, ọba Babiloni iranṣẹ òun, ní gbogbo àwọn ilẹ̀ wọnyi, òun sì ti fún un ni àwọn ẹranko inú igbó kí wọn máa ṣe iranṣẹ rẹ̀.

7 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóo máa ṣe ẹrú òun ati ọmọ rẹ̀, ati ọmọ ọmọ rẹ̀, títí àkókò tí ilẹ̀ òun pàápàá yóo fi tó, tí ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè ati àwọn ọba ńláńlá yóo sì kó o lẹ́rú.”

8 OLUWA ní, “Ṣugbọn bí orílẹ̀-èdè tabi ìjọba kan bá kọ̀, tí wọn kò sin Nebukadinesari, ọba Babiloni, tí wọn kò sì ti ọrùn wọn bọ àjàgà rẹ̀, ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn ni n óo fi jẹ orílẹ̀-èdè náà níyà títí n óo fi fà á lé ọba Babiloni lọ́wọ́.

9 Nítorí náà, ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wolii yín, ati àwọn awoṣẹ́ yín, àwọn alálàá yín ati àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, ati àwọn oṣó yín, tí wọn ń sọ fun yín pé ẹ kò ní di ẹrú ọba Babiloni.

10 Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fun yín, wọ́n fẹ́ kí á ko yín jìnnà sí ilẹ̀ yín ni. N óo le yín jáde; ẹ óo sì ṣègbé.

11 Ṣugbọn orílẹ̀-èdè tí ó bá ti ọrùn ara rẹ̀ bọ àjàgà ọba Babiloni, tí ó sì ń sìn ín, n óo fi sílẹ̀ lórí ilẹ̀ rẹ̀, kí ó lè máa ro ó, kí ó sì máa gbé ibẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

12 Iṣẹ́ yìí kan náà ni mo jẹ́ fún Sedekaya ọba Juda. Mo ní, “Fi ọrùn rẹ sinu àjàgà ọba Babiloni, kí o sin òun ati àwọn eniyan rẹ̀, kí o lè wà láàyè.

13 Kí ló dé tí ìwọ ati àwọn eniyan rẹ fẹ́ kú ikú idà, ikú ìyàn ati ikú àjàkálẹ̀ àrùn bí OLUWA ti wí pé yóo rí fún orílẹ̀-èdè tí ó bá kọ̀ tí kò bá sin ọba Babiloni?

14 Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wolii tí wọn ń wí fun yín pé ẹ kò ní ṣe ẹrú ọba Babiloni, nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fun yín.

15 OLUWA ní òun kò rán wọn níṣẹ́. Wọ́n kàn ń fi orúkọ òun sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni, kí òun lè le yín jáde, kí ẹ sì ṣègbé, àtẹ̀yin àtàwọn wolii tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fun yín.”

16 Lẹ́yìn náà, mo bá àwọn alufaa ati gbogbo àwọn eniyan náà sọ̀rọ̀, mo ní, “OLUWA sọ pé ẹ kò gbọdọ̀ fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn wolii yín tí wọn ń wí fun yín pé wọn kò ní pẹ́ kó àwọn ohun èlò ilé èmi OLUWA pada wá láti Babiloni. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fun yín.

17 Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wọn. Ẹ sin ọba Babiloni, kí ẹ lè wà láàyè. Kí ló dé tí ìlú yìí yóo fi di ahoro?

18 Bí wọn bá jẹ́ wolii nítòótọ́, bí ó bá jẹ́ pé èmi OLUWA ni mo fi ọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́nu, ẹ ní kí wọn gbadura sí èmi, OLUWA àwọn ọmọ ogun, kí n má jẹ́ kí wọ́n kó àwọn ohun èlò tí ó kù ní ilé OLUWA ati ní ààfin ọba Juda ati ní Jerusalẹmu lọ sí Babiloni.”

19 Àwọn ohun èlò kan ṣẹ́kù ninu ilé OLUWA, àwọn bíi: òpó ilé, ati agbada omi tí a fi idẹ ṣe, ati àwọn ìtẹ́lẹ̀ rẹ̀ ati àwọn ohun èlò tí ó kù ninu ìlú yìí,

20 tí Nebukadinesari, ọba Babiloni, kò kó lọ, nígbà tí ó kó Jehoiakini, ọba Juda, ọmọ Jehoiakimu, ati gbogbo àwọn ọlọ́lá Juda ati ti Jerusalẹmu lọ sí Babiloni.

21 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, “Gbogbo àwọn ohun èlò tí ó ṣẹ́kù ní ilé rẹ, ati ní ààfin ọba Juda, ati ní Jerusalẹmu, ni

22 wọn óo kó lọ sí Babiloni, níbẹ̀ ni wọn yóo sì wà títí di ọjọ́ tí mo bá ranti wọn. N óo wá kó wọn pada wá sí ibí yìí nígbà náà.”

28

1 Ní ọdún kan náà, ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekaya, ọba Juda, ní oṣù karun-un ọdún kẹrin, Hananaya wolii ọmọ Aṣuri, tí ó wá láti Gibeoni bá mi sọ̀rọ̀ ní ilé OLUWA lójú àwọn alufaa ati gbogbo àwọn eniyan pé,

2 “OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní òun ti ṣẹ́ àjàgà ọba Babiloni.

3 Kí ó tó pé ọdún meji, òun óo kó gbogbo ohun èlò tẹmpili òun pada, tí Nebukadinesari ọba Babiloni kó láti ibí yìí lọ sí Babiloni.

4 Òun óo mú Jehoiakini ọba Juda, ọmọ Jehoiakimu, ati gbogbo àwọn tí a kó lẹ́rú láti Juda lọ sí Babiloni pada sí ibí yìí, nítorí òun óo ṣẹ́ àjàgà ọba Babiloni. Ó ní OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.”

5 Jeremaya wolii bá dá Hananaya wolii lóhùn níṣojú àwọn alufaa ati gbogbo àwọn ará ìlú tí wọn dúró ní ilé OLUWA,

6 ó ní, “Amin, kí OLUWA ṣe bẹ́ẹ̀. Kí OLUWA mú àsọtẹ́lẹ̀ tí o sọ ṣẹ, kí ó kó àwọn ohun èlò ilé rẹ̀ ati gbogbo àwọn eniyan tí a kó lẹ́rú lọ sí Babiloni pada sí ibí yìí.

7 Ṣugbọn gbọ́ ohun tí n óo sọ fún ìwọ ati gbogbo àwọn eniyan wọnyi.

8 Àwọn wolii tí wọ́n ti wà ṣáájú èmi pẹlu rẹ ní ìgbà àtijọ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ìyàn, ati àjàkálẹ̀ àrùn nípa ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè ati nípa àwọn ìjọba ńláńlá.

9 Wolii tí ó bá fẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé alaafia yóo wà, nígbà tí ọ̀rọ̀ wolii náà bá ṣẹ ni a óo mọ̀ pé OLUWA ni ó rán an níṣẹ́ nítòótọ́.”

10 Hananaya wolii bá bọ́ àjàgà kúrò lọ́rùn Jeremaya, ó sì ṣẹ́ ẹ.

11 Hananaya bá sọ níṣojú gbogbo eniyan pé OLUWA ní bẹ́ẹ̀ ni òun óo ṣẹ́ àjàgà Nebukadinesari ọba Babiloni kúrò lọ́rùn gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè kí ọdún meji tó pé. Wolii Jeremaya bá bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.

12 Lẹ́yìn tí Hananaya wolii bọ́ àjàgà kúrò lọ́rùn Jeremaya, tí ó sì ṣẹ́ ẹ, OLUWA sọ fún Jeremaya pé,

13 “Lọ sọ fún Hananaya pé OLUWA ní àjàgà igi ni ó ṣẹ́, ṣugbọn àjàgà irin ni òun óo fi rọ́pò rẹ̀.

14 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní òun ti fi àjàgà irin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè wọnyi kí wọn lè di ẹrú Nebukadinesari ọba Babiloni, kí wọn sì máa sìn ín, nítorí òun ti fi àwọn ẹranko inú igbó pàápàá fún un.”

15 Jeremaya wolii bá sọ fún Hananaya pé, “Tẹ́tí sílẹ̀, Hananaya, OLUWA kò rán ọ níṣẹ́, o sì ń jẹ́ kí àwọn eniyan wọnyi gbẹ́kẹ̀lé irọ́.

16 Nítorí náà, OLUWA ní: òun óo mú ọ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ní ọdún yìí gan-an ni o óo sì kú, nítorí pé o ti sọ ọ̀rọ̀ ọ̀tẹ̀ sí OLUWA.”

17 Ní ọdún náà gan-an ní oṣù keje, ni Hananaya wolii kú.

29

1 Jeremaya wolii kọ ìwé kan ranṣẹ láti Jerusalẹmu, ó kọ ọ́ sí àwọn àgbààgbà láàrin àwọn tí a kó ní ìgbèkùn; ati sí àwọn alufaa ati àwọn wolii, ati gbogbo àwọn eniyan tí Nebukadinesari kó ní ìgbèkùn lọ sí Babiloni, láti Jerusalẹmu.

2 Ṣáájú àkókò yìí, ọba Jehoiakini ati ìyá ọba ti kúrò ní Jerusalẹmu, pẹlu àwọn ìwẹ̀fà ati àwọn ìjòyè Juda ati ti Jerusalẹmu, ati àwọn oníṣẹ́ ọwọ́ ati àwọn oníṣẹ́-ọnà.

3 Ó fi ìwé náà rán Elasa, ọmọ Ṣafani ati Gemaraya, ọmọ Hilikaya: àwọn tí Sedekaya, ọba Juda, rán lọ sọ́dọ̀ Nebukadinesari, ọba Babiloni.

4 Ó ní, “OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní kí n sọ fún gbogbo àwọn tí a ti kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babiloni pé,

5 ‘Ẹ máa kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé inú wọn, ẹ máa dá oko kí ẹ sì máa jẹ èso wọn.

6 Ẹ máa gbé iyawo kí ẹ bímọ lọkunrin ati lobinrin. Ẹ máa fẹ́ iyawo fún àwọn ọmọ yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọ yín fún ọkọ, kí wọn lè máa bímọ lọkunrin ati lobinrin. Ẹ máa pọ̀ sí i, ẹ má sì dínkù.

7 Ẹ máa wá alaafia ìlú tí mo ko yín lọ, ẹ máa gbadura sí OLUWA fún un, nítorí pé ninu alaafia rẹ̀ ni ẹ̀yin náà yóo ti ní alaafia.

8 Nítorí èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli sọ pé kí ẹ má jẹ́ kí àwọn wolii ati àwọn tí wọn ń woṣẹ́ láàrin yín tàn yín jẹ, kí ẹ má sì fetí sí àlá tí wọn ń lá;

9 nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fun yín ní orúkọ mi, n kò rán wọn níṣẹ́.’

10 “Nígbà tí aadọrin ọdún Babiloni bá pé, n óo mójú tó ọ̀rọ̀ yín, n óo mú ìlérí mi ṣẹ fun yín, n óo sì ko yín pada sí ibí yìí.

11 Nítorí pé mo mọ èrò tí mò ń gbà si yín, èrò alaafia ni, kì í ṣe èrò ibi. N óo mú kí ọjọ́ ọ̀la dára fun yín, n óo sì fun yín ní ìrètí.

12 Ẹ óo ké pè mí, ẹ óo gbadura sí mi, n óo sì gbọ́ adura yín.

13 Ẹ óo wá mi, ẹ óo sì rí mi, bí ẹ bá fi tọkàntọkàn wá mi.

14 Ẹ óo rí mi, n óo dá ire yín pada, n óo ko yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè ati láti gbogbo ibi tí mo ti le yín lọ; n óo sì ko yín pada sí ibi tí mo ti le yín kúrò lọ sí ìgbèkùn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

15 “Nítorí ẹ wí pé, ‘OLUWA ti gbé àwọn wolii dìde fun wa ní Babiloni.’

16 Nípa ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, ati gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú yìí, àní àwọn ará yín tí wọn kò ba yín lọ sí ìgbèkùn,

17 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, ‘N óo rán ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn sí wọn, n óo sì ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó bàjẹ́ tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè jẹ ẹ́.’

18 Ó ní, ‘N óo fi ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn bá wọn jà, òun óo sì sọ wọ́n di àríbẹ̀rù fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé. Wọn yóo di ẹni ègún, àríbẹ̀rù, àrípòṣé ati ẹni ẹ̀sín láàrin àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé wọn lọ.

19 Nítorí pé wọn kò fetí sí ọ̀rọ̀ tí mo rán àwọn iranṣẹ mi, àwọn wolii, láti sọ fún wọn nígbà gbogbo.

20 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA sọ, gbogbo ẹ̀yin tí OLUWA kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babiloni.’

21 “Ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Jehoiakini, ati Sedekaya ọmọ Maaseaya, tí wọn ń forúkọ mi sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fun yín ni pé: òun óo fi wọ́n lé Nebukadinesari ọba Babiloni lọ́wọ́, yóo sì pa wọ́n lójú yín.

22 Gbogbo àwọn ará Juda tí wọ́n wà ní ìgbèkùn ní Babiloni yóo máa fi ọ̀rọ̀ wọn ṣépè fún eniyan pé: ‘OLUWA yóo ṣe ọ́ bíi Sedekaya ati Ahabu tí ọba Babiloni sun níná,’

23 nítorí pé wọ́n ti hùwà òmùgọ̀ ní Israẹli, wọ́n bá aya àwọn aládùúgbò wọn ṣe àgbèrè, wọ́n fi orúkọ òun sọ ọ̀rọ̀ èké tí òun kò fún wọn láṣẹ láti sọ. OLUWA ní òun nìkan ni òun mọ ohun tí wọ́n ṣe; òun sì ni ẹlẹ́rìí.”

24 OLUWA ní kí n sọ fún Ṣemaaya tí ń gbé Nehelamu pé,

25 “Èmi, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, nítorí ìwé tí o fi orúkọ ara rẹ kọ sí gbogbo àwọn eniyan tí wọ́n wà ní Jerusalẹmu, ati sí Sefanaya alufaa, ọmọ Maaseaya, ati sí gbogbo àwọn alufaa, pé:

26 “Èmi OLUWA ti fi ìwọ Sefanaya jẹ alufaa dípò Jehoiada tí ó jẹ́ alufaa tẹ́lẹ̀ rí, ati pé mo ní kí o máa ṣe alabojuto gbogbo àwọn wèrè tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé èmi OLUWA, kí o sì máa kan ààbà mọ́ wọn ní ẹsẹ̀, kí o máa fi okùn sí wọn lọ́rùn.

27 Kí ló dé tí o kò bá Jeremaya ará Anatoti tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fun yín wí.

28 Nítorí ó ti ranṣẹ sí wa ní Babiloni pé a á pẹ́ níbí, nítorí náà kí á kọ́lé, kí á máa gbé inú rẹ̀, kí á dá oko, kí á sì máa jẹ èso rẹ̀.”

29 Sefanaya Alufaa ka ìwé náà sí etí Jeremaya wolii.

30 OLUWA bá sọ fún Jeremaya pé,

31 “Ranṣẹ sí gbogbo àwọn tí wọ́n wà ní ìgbèkùn wí pé ohun tí OLUWA wí nípa Ṣemaaya ará Nehelamu ni pé: nítorí pé Ṣemaaya sọ àsọtẹ́lẹ̀ tí òun kò rán an, ó sì mú kí ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ èké,

32 òun OLUWA óo fìyà jẹ Ṣemaaya ará Nehelamu náà ati ìran rẹ̀; kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóo wà láàyè láàrin àwọn eniyan rẹ̀ láti fojú rí nǹkan rere tí n óo ṣe fún àwọn eniyan mi, nítorí ó ti sọ̀rọ̀ ọ̀tẹ̀ sí OLUWA.”

30

1 OLUWA Ọlọrun Israẹli bá Jeremaya sọ̀rọ̀:

2 Ó ní, “Kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún ọ sinu ìwé,

3 nítorí pé àkókò ń bọ̀ tí n óo dá ire àwọn eniyan mi, Israẹli ati Juda pada. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo mú wọn pada wá sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn, yóo sì di ohun ìní wọn.”

4 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA sọ nípa Israẹli ati Juda nìyí:

5 “A ti gbọ́ igbe ìdágìrì ati ti ẹ̀rù, kò sì sí alaafia.

6 Ẹ bèèrè, kí ẹ sì ṣe ìwádìí; ǹjẹ́ ọkunrin lè lóyún kí ó sì bímọ? Kí ló wá dé tí mo rí gbogbo ọkunrin, tí wọn ń dáwọ́ tẹ ìbàdí bí obinrin tí ń rọbí? Kí ló dé tí gbogbo yín fajúro?

7 Ọjọ́ ńlá lọjọ́ náà yóo jẹ́, kò sí ọjọ́ tí yóo dàbí rẹ̀, àkókò ìpọ́njú ni yóo jẹ́ fún ilé Jakọbu; ṣugbọn wọn yóo bọ́ ninu rẹ̀.”

8 OLUWA ní, “Nígbà tí ó bá yá, n óo já àjàgà kúrò lọ́rùn wọn. N óo já ẹ̀wọ̀n tí wọ́n fi so wọ́n, wọn kò sì ní ṣe iranṣẹ fún àjèjì mọ́.

9 Ṣugbọn wọn yóo máa sin Ọlọrun wọn, ati ti Dafidi, ọba wọn, tí n óo gbé dìde fún wọn.

10 “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin eniyan Jakọbu, iranṣẹ mi, ẹ má sì jẹ́ kí àyà fò yín, ẹ̀yin ọmọ Israẹli. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo ti òkèèrè wá gbà yín là, N óo gba àwọn ọmọ yín tí wọ́n wà ní ìgbèkùn là pẹlu. Àwọn ọmọ Jakọbu yóo pada ní ìfọ̀kànbalẹ̀ ati ìrọ̀rùn, ẹnikẹ́ni kò sì ní dẹ́rù bà wọ́n mọ́.

11 Nítorí pé mo wà pẹlu yín, n óo gbà yín là. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n óo pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo fọn yín ká sí ni n óo parun patapata, ṣugbọn n kò ní pa ẹ̀yin run. N óo jẹ yín níyà, ṣugbọn n kò ní fi ìyà tí kò tọ́ jẹ yín. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

12 “Egbò yín kò lè san mọ́, ọgbẹ́ yín sì jinlẹ̀.

13 Kò sí ẹni tí yóo gba ẹjọ́ yín rò, kò ní sí òògùn fún ọgbẹ́ yín, kò ní sí ìwòsàn fun yín.

14 Gbogbo àwọn olólùfẹ́ yín ti gbàgbé yín; wọn kò bìkítà nípa yín mọ́, nítorí mo ti nà yín bí ọ̀tá mi, mo sì fi ìyà jẹ yín bí ọ̀tá tí kò láàánú, nítorí àṣìṣe yín pọ̀, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ rékọjá ààlà.

15 Kí ló dé tí ẹ̀ ń sunkún, nítorí ìnira yín tí kò lóògùn? Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ rékọjá ààlà ni mo ṣe jẹ́ kí àwọn nǹkan wọnyi dé ba yín.

16 Ṣugbọn, gbogbo àwọn tí wọ́n bá jẹ yín run, ni a óo pada jẹ run. Gbogbo àwọn ọ̀tá yín patapata, ni yóo lọ sí ìgbèkùn. Gbogbo àwọn tí wọ́n fogun kó yín ni ogun yóo kó. N óo fi ẹrù àwọn tí wọn ń jà yín lólè fún àwọn akónilẹ́rù.

17 N óo fun yín ní ìlera, n óo sì wo àwọn ọgbẹ́ yín sàn, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Nítorí wọ́n ti pè yín ní ‘Ẹni ìtanù, Sioni tí ẹnikẹ́ni kò bìkítà fún.’ ”

18 OLUWA ní, “Mo ṣetán láti dá ire ilé Jakọbu pada, n óo fi ojurere wo ibùgbé rẹ̀. A óo tún ìlú náà kọ́ sórí òkítì rẹ̀, a óo sì tún kọ́ ààfin rẹ̀ sí ààyè rẹ̀ tẹ́lẹ̀.

19 Orin ọpẹ́ yóo máa ti ibẹ̀ jáde wá, a óo sì máa gbọ́ ohùn àwọn tí ń ṣe àríyá pẹlu. N óo bukun wọn, wọn óo di pupọ, n óo sọ wọ́n di ẹni iyì, wọn kò sì ní jẹ́ eniyan yẹpẹrẹ.

20 Àwọn ọmọ wọn yóo rí bí wọn ti rí ní àtijọ́, àwọn ìjọ wọn yóo fi ìdí múlẹ̀ níwájú mi. N óo sì fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí wọn ń ni wọ́n lára.

21 Ọ̀kan ninu wọn ni yóo jọba lórí wọn, ààrin wọn ni a óo sì ti yan olórí wọn; n óo fà á mọ́ra, yóo sì súnmọ́ mi, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè fúnra rẹ̀ súnmọ́ mi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

22 Ẹ óo jẹ́ eniyan mi, n óo sì jẹ́ Ọlọrun yín.”

23 Ẹ wo ìjì OLUWA! Ibinu rẹ̀ ń bọ̀ bí ìjì líle. Ó ń bọ̀ sórí àwọn oníṣẹ́ ibi.

24 Ibinu gbígbóná OLUWA kò ní yipada, títí yóo fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Òye nǹkan wọnyi yóo ye yín ní ọjọ́ ìkẹyìn.

31

1 OLUWA ní, “Àkókò ń bọ̀ tí n óo jẹ́ Ọlọrun gbogbo ìdílé Israẹli, tí àwọn náà yóo sì jẹ́ eniyan mi.

2 Àwọn tí wọ́n bọ́ lọ́wọ́ idà, rí àánú OLUWA ninu aṣálẹ̀; nígbà tí Israẹli ń wá ìsinmi,

3 OLUWA yọ sí wọn láti òkèèrè. Ìfẹ́ àìlópin ni mo ní sí ọ, nítorí náà n kò ní yé máa fi òtítọ́ bá ọ lò.

4 N óo tún yín gbé dìde, ẹ óo sì di ọ̀tun, ẹ̀yin ọmọ Israẹli. Ẹ óo tún fi aro lu ìlù ayọ̀, ẹ óo sì jó ijó ìdùnnú.

5 Ẹ óo tún ṣe ọgbà àjàrà sórí òkè Samaria; àwọn tí wọ́n gbin àjàrà ni yóo sì gbádùn èso orí rẹ̀.

6 Nítorí pé ọjọ́ kan ń bọ̀, tí àwọn aṣọ́nà yóo pè yín láti orí òkè Efuraimu pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí á lọ sí òkè Sioni, sí ọ̀dọ̀ OLUWA Ọlọrun wa.’ ”

7 OLUWA ní, “Ẹ kọ orin sókè pẹlu ìdùnnú fún Jakọbu, kí ẹ sì hó fún olórí àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ kéde, ẹ kọ orin ìyìn, kí ẹ sì wí pé, ‘OLUWA ti gba àwọn eniyan rẹ̀ là àní, àwọn eniyan Israẹli yòókù.’

8 Ẹ wò ó! N óo kó wọn wá láti ilẹ̀ àríwá, n óo kó wọn jọ láti òpin ayé. Àwọn afọ́jú ati arọ yóo wà láàrin wọn, ati aboyún ati àwọn tí wọn ń rọbí lọ́wọ́. Ogunlọ́gọ̀ eniyan ni àwọn tí yóo pada wá síbí.

9 Tẹkúntẹkún ni wọn yóo wá, tàánútàánú ni n óo sì fi darí wọn pada. N óo mú kí wọn rìn ní etí odò tí ń ṣàn, lójú ọ̀nà tààrà, níbi tí wọn kò ti ní fẹsẹ̀ kọ; nítorí pé baba ni mo jẹ́ fún Israẹli, àkọ́bí mi sì ni Efuraimu.”

10 OLUWA ní, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ èmi OLUWA, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí ẹ sì kéde rẹ̀ ní èbúté lókèèrè réré; ẹ sọ pé, ‘Ẹni tí ó fọ́n Israẹli ká ni yóo kó wọn jọ, yóo sì máa tọ́jú wọn, bí olùṣọ́-aguntan tíí tọ́jú agbo aguntan rẹ̀.’

11 Nítorí OLUWA yóo ra ilé Jakọbu pada, yóo rà wọ́n pada lọ́wọ́ ẹni tí ó lágbára jù wọ́n lọ.

12 Wọn yóo wá kọrin lórí òkè Sioni, wọn óo sì yọ̀ lórí nǹkan ọ̀pọ̀ oore tí OLUWA yóo ṣe fún wọn: Wọ́n óo yọ̀ nítorí oore ọkà ati waini ati òróró, ati aguntan ati ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù; ayé wọn óo dàbí ọgbà tí à ń bomi rin, wọn kò ní dààmú mọ́.

13 Àwọn ọdọmọbinrin óo máa jó ijó ayọ̀ nígbà náà, àwọn ọdọmọkunrin ati àwọn àgbààgbà, yóo sì máa ṣe àríyá. N óo sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, n óo tù wọ́n ninu, n óo sì fún wọn ní ayọ̀ dípò ìbànújẹ́ wọn.

14 N óo fún àwọn alufaa ní ọpọlọpọ oúnjẹ, n óo sì fi oore mi tẹ́ àwọn eniyan mi lọ́rùn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

15 OLUWA ní, “A gbọ́ ohùn kan ní Rama, ariwo ẹkún ẹ̀dùn ati arò ni. Rakẹli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n ṣìpẹ̀ fún un títí, kò gbà, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ tí kò sí mọ́.

16 Má sọkún mọ́, nu ojú rẹ nù, nítorí o óo jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ. Àwọn ọmọ rẹ yóo pada wá láti ilẹ̀ ọ̀tá wọn.

17 Ìrètí ń bẹ fún ọ lẹ́yìn ọ̀la, àwọn ọmọ rẹ yóo pada sí orílẹ̀-èdè wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

18 “Mo gbọ́ bí Efuraimu tí ń kẹ́dùn, ó ní: ‘O ti bá mi wí, ìbáwí sì dùn mí, bí ọmọ mààlúù tí a kò kọ́. Mú mi pada, kí n lè pada sí ààyè mi, nítorí pé ìwọ ni OLUWA, Ọlọrun mi.

19 Nítorí pé lẹ́yìn tí mo ṣáko lọ, mo ronupiwada; lẹ́yìn tí o kọ́ mi lọ́gbọ́n, ń ṣe ni mo káwọ́ lérí. Ojú tì mí, ìdààmú sì bá mi, nítorí ìtìjú ohun tí mo ṣe nígbà èwe mi dé bá mi.’

20 “Ṣé ọmọ mi ọ̀wọ́n ni Efuraimu ni? Ṣé ọmọ mi àtàtà ni? Nítorí bí mo tí ń sọ̀rọ̀ ibinu sí i tó, sibẹ mò ń ranti rẹ̀, nítorí náà ọkàn rẹ̀ ń fà mí; dájúdájú n óo ṣàánú rẹ̀.

21 Ẹ ri òpó mọ́lẹ̀ lọ fún ara yín, ẹ sàmì sí àwọn ojú ọ̀nà. Ẹ wo òpópónà dáradára, ẹ fiyèsí ọ̀nà tí ẹ gbà lọ. Ẹ yipada, ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ pada sí àwọn ìlú yín wọnyi.

22 Ìgbà wo ni ẹ óo ṣe iyèméjì dà, ẹ̀yin alainigbagbọ wọnyi? Nítorí OLUWA ti dá ohun titun sórí ilẹ̀ ayé, bíi kí obinrin máa dáàbò bo ọkunrin.”

23 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, “Lẹ́ẹ̀kan sí i, wọn yóo tún máa lo gbolohun yìí ní ilẹ̀ Juda ati ní àwọn ìlú rẹ̀, nígbà tí mo bá dá ire wọn pada, wọn óo máa wí pé, ‘OLUWA yóo bukun ọ, ìwọ òkè mímọ́ Jerusalẹmu, ibùgbé olódodo.’

24 Àwọn eniyan yóo máa gbé àwọn ìlú Juda ati àwọn agbègbè rẹ̀ pẹlu àwọn àgbẹ̀ ati àwọn darandaran.

25 Nítorí pé n óo fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní agbára; n óo sì tu gbogbo ọkàn tí ń kérora lára.”

26 Lẹ́sẹ̀ kan náà mo tají, mo wò yíká, oorun tí mo sùn sì dùn mọ́ mi.

27 OLUWA ní, “Ọjọ́ ń bọ̀ tí n óo kó àtènìyàn, àtẹranko kún ilẹ̀ Israẹli ati ilẹ̀ Juda.

28 Nígbà tí àkókò bá tó, gẹ́gẹ́ bí mo tí ń ṣọ́ wọn tí mo fi fà wọ́n tu, tí mo wó wọn lulẹ̀, tí mo bì wọ́n wó, tí mo pa wọ́n run, tí mo sì mú kí ibi ó bá wọn; bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣọ́ wọn tí n óo fi kọ́ àwọn ìlú wọn tí n óo sì fìdí wọn múlẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

29 Tó bá dìgbà náà, àwọn eniyan kò ní máa wí mọ́ pé, ‘Àwọn baba ni wọ́n jẹ èso àjàrà kíkan, àwọn ọmọ wọn ni eyín kan.’

30 Kàkà bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó bá jẹ èso àjàrà kíkan, òun ni eyín yóo kan. Olukuluku ni yóo kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀.

31 “Ọjọ́ ń bọ̀, tí ń óo bá ilé Israẹli ati ilé Juda dá majẹmu titun.

32 Kì í ṣe irú majẹmu tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, ní ìgbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́ jáde ní ilẹ̀ Ijipti, àní majẹmu mi tí wọn dà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi ni ọkọ wọn.

33 Ṣugbọn majẹmu tí n óo bá ilé Israẹli dá nígbà tó bá yá nìyí: N óo fi òfin mi sí inú wọn, n óo sì kọ wọ́n sí ọkàn wọn. N óo máa jẹ́ Ọlọrun wọn, wọn yóo sì máa jẹ́ eniyan mi.

34 Ẹnikẹ́ni kò ní máa kọ́ aládùúgbò rẹ̀ tabi arakunrin rẹ̀ bí a ti í mọ èmi OLUWA mọ́, gbogbo wọn ni wọn yóo mọ̀ mí ati àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki. N óo dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n, n kò sì ní ranti àìdára wọn mọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

35 OLUWA ni ó dá oòrùn, láti máa ràn ní ọ̀sán, tí ó fún òṣùpá ati ìràwọ̀ láṣẹ, láti tan ìmọ́lẹ̀ lálẹ́, tí ó rú omi òkun sókè, tí ìgbì rẹ̀ ń hó yaya, òun ni orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun.

36 Òun ló sọ pé, àfi bí àwọn àṣẹ wọnyi bá yipada níwájú òun, ni àwọn ọmọ Israẹli kò fi ní máa jẹ́ orílẹ̀-èdè títí lae.

37 Àfi bí eniyan bá lè wọn ojú ọ̀run, tí ó sì lè wádìí ìpìlẹ̀ ayé, ni òun lè ké àwọn ọmọ Israẹli kúrò, nítorí gbogbo ohun tí wọ́n ṣe.

38 OLUWA ni, “Ẹ wò ó! Àkókò ń bọ̀ tí a óo tún Jerusalẹmu kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli títí dé Bodè Igun.

39 A óo ta okùn ìwọ̀n odi ìlú títí dé òkè Garebu, ati títí dé Goa pẹlu.

40 Gbogbo àfonífojì tí wọn ń da òkú ati eérú sí, ati gbogbo pápá títí dé odò Kidironi, dé ìkangun Bodè Ẹṣin, ní ìhà ìlà oòrùn, ni yóo jẹ́ ibi mímọ́ fún OLUWA. Wọn kò ní fọ́ ọ mọ́, ẹnìkan kò sì ní wó o lulẹ̀ títí laelae.”

32

1 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ ní ọdún kẹwaa tí Sedekaya jọba ní Juda, tí ó jẹ́ ọdún kejidinlogun tí Nebukadinesari jọba.

2 Àwọn ọmọ ogun Babiloni dó ti Jerusalẹmu ní àkókò yìí, Jeremaya wolii sì wà ní ẹ̀wọ̀n tí wọ́n sọ ọ́ sí, ní àgbàlá ààfin ọba Juda.

3 Sedekaya ọba Juda ni ó sọ Jeremaya sẹ́wọ̀n, ó ní, kí ló dé tí Jeremaya fi sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé OLUWA ní òun óo fi Jerusalẹmu lé ọba Babiloni lọ́wọ́, yóo sì gbà á;

4 ati pé Sedekaya ọba Juda kò ní bọ́ lọ́wọ́ àwọn ará Kalidea. Ó ní Jeremaya sọ pé dájúdájú, OLUWA óo fi òun Sedekaya lé ọba Babiloni lọ́wọ́, àwọn yóo rí ara àwọn lojukooju, àwọn yóo sì bá ara àwọn sọ̀rọ̀.

5 Yóo mú òun Sedekaya lọ sí Babiloni, ibẹ̀ ni òun óo sì wà títí OLUWA yóo fi ṣe ẹ̀tọ́ fún òun. Ó ní bí àwọn tilẹ̀ bá àwọn ará Kalidea jagun, àwọn kò ní borí.

6 Jeremaya ní, “OLUWA sọ fún mi pé,

7 ‘Hanameli ọmọ Ṣalumu, arakunrin baba rẹ, yóo wá bá ọ pé kí o ra oko òun tí ó wà ní Anatoti, nítorí pé ìwọ ni ó tọ́ sí láti rà á pada.’

8 Lẹ́yìn náà Hanameli ọmọ arakunrin baba mi tọ̀ mí wá sí àgbàlá àwọn olùṣọ́ gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti sọ, ó sì wí fún mi pé, ‘Jọ̀wọ́ ra oko mi tí ó wà ní Anatoti ní ilẹ̀ Bẹnjamini, nítorí pé ìwọ ni ó tọ́ sí láti rà á pada; rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni mo wá mọ̀ pé àṣẹ OLUWA ni.

9 Mo bá ra oko náà lọ́wọ́ Hanameli ọmọ arakunrin baba mi, mo sì wọn fadaka ṣekeli mẹtadinlogun fún un.

10 Mo kọ ọ́ sinu ìwé, mo fi òǹtẹ̀ tẹ̀ ẹ́, mo pe àwọn eniyan láti ṣe ẹlẹ́rìí; mo sì fi òṣùnwọ̀n wọn fadaka náà.

11 Mo mú ìwé ilẹ̀ náà tí a ti fi òǹtẹ̀ tẹ̀ ati ẹ̀dà rẹ̀,

12 mo sì fún Baruku ọmọ Neraya ọmọ Mahiseaya ní èyí tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀, níṣojú Hanameli, ọmọ arakunrin baba mi ati níṣojú àwọn ẹlẹ́rìí tí wọn fọwọ́ sí ìwé ilẹ̀ náà, ati níṣojú gbogbo àwọn ará Juda tí wọn jókòó ní àgbàlá àwọn olùṣọ́ náà.

13 Mo pàṣẹ fún Baruku níṣojú wọn pé,

14 ‘OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní kí o mú ìwé ilẹ̀ yìí, ati èyí tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀ tí a sì ká, ati ẹ̀dà rẹ̀, kí o fi wọ́n sinu ìkòkò amọ̀ kí wọ́n lè wà níbẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́.

15 Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli sọ pé: wọn yóo tún máa ra ilẹ̀ ati oko ati ọgbà àjàrà ní ilẹ̀ yìí.’

16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé ilẹ̀ náà lé Baruku ọmọ Neraya lọ́wọ́, mo gbadura sí OLUWA, mo ní:

17 ‘OLUWA, Ọlọrun! Ìwọ tí o dá ọ̀run ati ayé pẹlu agbára ńlá ati ipá rẹ! Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ,

18 ìwọ tí ò ń fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn fún ẹgbẹẹgbẹrun eniyan, ṣugbọn tí ò ń gba ẹ̀san àwọn baba lára àwọn ọmọ wọn lẹ́yìn ikú wọn, ìwọ Ọlọrun alágbára ńlá tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun,

19 ìwọ Olùdámọ̀ràn ńlá, tí ó lágbára ní ìṣe; ìwọ tí ojú rẹ ń rí sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ eniyan, tí o sì ń san ẹ̀san fún olukuluku gẹ́gẹ́ bí ìwà ati iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀;

20 ìwọ tí o ṣe iṣẹ́ abàmì, ati iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Ijipti, o sì tún ń ṣe iṣẹ́ náà títí di òní ní Israẹli ati láàrin gbogbo eniyan; o sì ti fìdí orúkọ rẹ múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti rí lónìí.

21 Ìwọ ni o kó àwọn ọmọ Israẹli, àwọn eniyan rẹ, jáde láti ilẹ̀ Ijipti pẹlu iṣẹ́ abàmì ati iṣẹ́ ìyanu, pẹlu ọwọ́ agbára, ipá ati ìbẹ̀rù ńlá.

22 O sì fún wọn ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí o búra fún àwọn baba ńlá wọn pé o óo fún wọn, ilẹ̀ tí ó kún fún wàrà ati oyin.

23 Wọ́n dé ilẹ̀ náà, wọ́n sì gbà á; ṣugbọn wọn kò gbọ́rọ̀ sí ọ lẹ́nu, wọn kò sì pa òfin rẹ mọ́. Wọn kò ṣe ọ̀kan kan ninu gbogbo ohun tí o pàṣẹ fún wọn láti máa ṣe; nítorí náà ni o ṣe mú kí gbogbo ibi tí ó ṣẹlẹ̀ sí wọn bá wọn!

24 “ ‘Wo bí àwọn ọ̀tá ti mọ òkítì sí ara odi wa láti gba ìlú wa. Nítorí ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn, a óo fi ìlú yìí lé àwọn ará Kalidea tí wọn gbógun tì í lọ́wọ́. Ohun tí o wí ṣẹ, o sì ti rí i.

25 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti fi ìlú yìí lé àwọn ará Kalidea lọ́wọ́, sibẹsibẹ, ìwọ OLUWA Ọlọrun ni o sọ fún mi pé kí n ra ilẹ̀, kí n sì ní àwọn ẹlẹ́rìí.’ ”

26 OLUWA sọ fún Jeremaya pé,

27 “Wò ó! Èmi ni OLUWA, Ọlọrun gbogbo eniyan, ǹjẹ́ nǹkankan wà tí ó ṣòro fún mi láti ṣe?

28 Nítorí náà èmi OLUWA ni mo sọ pé, n óo fi ìlú yìí lé àwọn ará Kalidea ati Nebukadinesari, ọba Babiloni lọ́wọ́, yóo sì gbà á.

29 Àwọn ará Kalidea tí wọn gbógun ti ìlú yìí, yóo wọ inú rẹ̀, wọn yóo sì dáná sun ún pẹlu àwọn ilẹ̀ tí wọ́n tí ń sun turari sí oriṣa Baali lórí wọn, tí wọ́n sì tí ń rú ẹbọ ohun mímu sí àwọn oriṣa tí wọn ń mú mi bínú.

30 Nítorí láti ìgbà èwe àwọn ọmọ Israẹli ati àwọn eniyan Juda ni wọ́n tí ń ṣe kìkì nǹkan tí ó burú lójú mi, kìkì nǹkan tí yóo bí mi ninu ni àwọn ọmọ Israẹli náà sì ń ṣe. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

31 Láti ọjọ́ tí wọn ti tẹ ìlú yìí dó títí di òní, ni àwọn ará ilẹ̀ yìí tí ń mú mi bínú, tí wọn sì ń mú kí inú mi ó máa ru, kí n lè pa wọ́n rẹ́ kúrò níwájú mi,

32 nítorí gbogbo ibi tí àwọn ọmọ Israẹli ati àwọn ará ilẹ̀ Juda ṣe láti mú mi bínú, àtàwọn ọba wọn, àtàwọn ìjòyè wọn, àtàwọn alufaa wọn, àtàwọn wolii wọn; àtàwọn ará Juda àtàwọn tí ń gbé Jerusalẹmu.

33 Wọ́n ti yíjú kúrò lọ́dọ̀ mi, wọ́n sì kẹ̀yìn sí mi. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti kọ́ wọn ni àkọ́túnkọ́, wọn kò gba ẹ̀kọ́.

34 Wọ́n gbé àwọn ère wọn, tí ó jẹ́ ohun ìríra fun mi sinu ilé tí à ń fi orúkọ mi pè, kí wọ́n lè sọ ọ́ di ibi àìmọ́.

35 Wọ́n kọ́ ojúbọ oriṣa tí ó wà ní àfonífojì ọmọ Hinomu láti máa fi àwọn ọmọ wọn, lọkunrin ati lobinrin rú ẹbọ sí oriṣa Moleki, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò pa á láṣẹ fún wọn, tí kò sì wá sí mi lọ́kàn pé wọ́n lè ṣe irú ohun ìríra bẹ́ẹ̀, láti mú Juda dẹ́ṣẹ̀.”

36 Nítorí náà, OLUWA Ọlọrun Israẹli sọ fún mi pé, “Ìlú tí àwọn eniyan ń sọ pé ọwọ́ ọba Babiloni ti tẹ̀, nítorí ogun, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn,

37 n óo kó àwọn eniyan ibẹ̀ jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti fi ibinu, ìrúnú, ati ìkanra lé wọn lọ; n óo kó wọn pada sí ibí yìí, n óo sì mú kí wọn máa gbé ní àìléwu.

38 Wọn yóo máa jẹ́ eniyan mi, Èmi náà óo sì máa jẹ́ Ọlọrun wọn.

39 N óo fún wọn ní ọkàn ati ẹ̀mí kan, kí wọn lè máa bẹ̀rù mi nígbà gbogbo, kí ó lè dára fún àwọn ati àwọn ọmọ wọn lẹ́yìn wọn.

40 N óo bá wọn dá majẹmu ayérayé, pé n kò ní dẹ́kun ati máa ṣe wọ́n lóore. N óo fi ẹ̀rù mi sí wọn lọ́kàn, kí wọn má baà yapa kúrò lọ́dọ̀ mi mọ́.

41 Yóo máa jẹ́ ohun ayọ̀ fún mi láti ṣe wọ́n lóore, n óo fi tẹ̀mítẹ̀mí ati tọkàntọkàn fi ìdí wọn múlẹ̀ ninu jíjẹ́ olóòótọ́ ní ilẹ̀ yìí.

42 “Bí mo ṣe mú gbogbo ibi ńlá yìí bá àwọn eniyan wọnyi, bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe mú kí gbogbo ohun rere tí mo ti ṣe ìlérí fún wọn dé bá wọn.

43 Wọn yóo ra oko ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ẹ̀ ń sọ pé ó ti di ahoro, tí kò sí eniyan tabi ẹranko ninu rẹ̀, tí ẹ̀ ń sọ pé a ti fi lé àwọn ará Kalidea lọ́wọ́.

44 Wọn yóo máa fi owó ra oko, wọn yóo máa ṣe ìwé ilẹ̀, wọn yóo máa fi òǹtẹ̀ tẹ̀ ẹ́; wọn yóo máa fi èdìdì dì í, àwọn ẹlẹ́rìí yóo sì máa fi ọwọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni yóo máa rí ní ilẹ̀ Bẹnjamini. Nígbà tí mo bá dá ire wọn pada, ati ní àwọn agbègbè Jerusalẹmu, ní àwọn ìlú Juda, ati àwọn ìlú agbègbè olókè, ní àwọn ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ṣefela, ati àwọn ìlú ilẹ̀ Nẹgẹbu. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

33

1 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ lẹẹkeji, nígbà tí ó ṣì wà ní ẹ̀wọ̀n, ní àgbàlá àwọn tí ń ṣọ́ ààfin.

2 OLUWA tí ó dá ayé, tí ó sì fìdí rẹ̀ múlẹ̀, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA, ni ó sọ pé:

3 “Ẹ ké pè mí, n óo sì da yín lóhùn; n óo sọ nǹkan ìjìnlẹ̀ ati ìyanu ńlá, tí ẹ kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ fun yín.”

4 OLUWA, Ọlọrun Israẹli sọ nípa àwọn ilé tí wọ́n wà ní ìlú yìí, ati ilé ọba Juda, àwọn tí wọn dótì wá, tí wọn ń gbógun tì wá yóo wó wọn lulẹ̀

5 Ó ní, “Àwọn ará Kalidea ń gbógun bọ̀, wọn yóo da òkú àwọn eniyan tí n óo fi ibinu ati ìrúnú pa kún àwọn ilé tí ó wà ní ìlú yìí, nítorí mo ti fi ara pamọ́ fún ìlú yìí nítorí gbogbo ìwà burúkú wọn.

6 N óo mú ìlera ati ìwòsàn wá bá wọn; n óo wò wọ́n sàn, n óo sì fún wọn ní ọpọlọpọ ibukun ati ìfọ̀kànbalẹ̀.

7 N óo dá ire Juda ati ti Israẹli pada, n óo sì tún wọn kọ́, wọn yóo dàbí wọ́n ti rí lákọ̀ọ́kọ́.

8 N óo wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò ninu gbogbo ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n dá sí mi, n óo dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ati oríkunkun tí wọ́n ṣe sí mi jì wọ́n.

9 Orúkọ ìlú yìí yóo sì jẹ́ orúkọ ayọ̀ fún mi, yóo jẹ́ ohun ìyìn ati ògo níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé tí yóo gbọ́ nípa nǹkan rere tí n óo ṣe fún wọn; ẹ̀rù yóo bà wọ́n, wọn yóo sì wárìrì, nítorí gbogbo nǹkan rere tí n óo máa ṣe fún ìlú náà.”

10 OLUWA ní, “A óo tún gbọ́ ohùn ayọ̀ ati inú dídùn ninu ìlú Juda ati ìgboro Jerusalẹmu, tí ẹ sọ wí pé ó ti di ahoro, tí kò sí eniyan tabi ẹranko tó ń gbé inú wọn.

11 A óo tún gbọ́ ohùn ọkọ iyawo ati ohùn iyawo ati ohùn àwọn tí wọn ń kọrin bí wọ́n ti ń mú ẹbọ ọpẹ́ wá sinu ilé OLUWA wí pé: 107:1; 118:1; 136:1 ‘Ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA àwọn ọmọ ogun, nítorí pé rere ni OLUWA, nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae!’ Nítorí pé n óo dá ire wọn pada bíi ti ìgbà àtijọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

12 OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ pé, “Ní gbogbo ibi tí ó ti di ahoro yìí, tí eniyan tabi ẹranko kò gbé ibẹ̀, àwọn olùṣọ́-aguntan yóo sì tún máa tọ́jú àwọn agbo ẹran wọn ninu gbogbo àwọn ìlú ibẹ̀.

13 Àwọn agbo ẹran yóo tún kọjá níwájú ẹni tí ó ń kà wọ́n ninu àwọn ìlú tí wọ́n wà ní agbègbè olókè, ati àwọn ti pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ṣefela ati àwọn ìlú tí wọn wà ní Nẹgẹbu, ní ilẹ̀ Bẹnjamini, ní agbègbè tí ó yí Jerusalẹmu ká, ati àwọn ìlú Juda. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

14 Ó ní, “Àkókò ń bọ̀, tí n óo mú ìlérí tí mo ṣe fún ilé Israẹli ati ilé Juda ṣẹ.

15 Nígbà tó bá yá, tí àkókò bá tó, n óo mú kí ẹ̀ka òdodo kan ó sọ jáde ní ilé Dafidi, yóo máa ṣe ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ati ti òdodo ní ilẹ̀ náà.

16 A óo gba Juda là, Jerusalẹmu yóo sì wà ní àìléwu, orúkọ tí a óo wá máa pè é ni ‘OLÚWA ni Òdodo wa.’ ”

17 Nítorí OLUWA ní kò ní sí ìgbà kan, tí kò ní jẹ́ pé ọkunrin kan ní ilé Dafidi ni yóo máa jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli,

18 bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní sí ìgbà kan tí ẹnìkan ninu àwọn alufaa, ọmọ Lefi, kò ní máa dúró níwájú òun láti rú ẹbọ sísun ati ẹbọ ohun jíjẹ, láti máa rú ẹbọ títí lae.

19 OLUWA tún bá Jeremaya sọ̀rọ̀;

20 ó ní, “Bí ẹ bá lè ba majẹmu tí mo bá ọ̀sán ati òru dá jẹ́, tí wọn kò fi ní wà ní àkókò tí mo yàn fún wọn mọ́,

21 òun nìkan ni majẹmu tí mo bá Dafidi iranṣẹ mi dá ṣe lè yẹ̀, tí ìdílé rẹ̀ kò fi ní máa ní ọmọkunrin kan tí yóo jọba; bẹ́ẹ̀ náà ni majẹmu tí mo bá àwọn alufaa, ọmọ Lefi iranṣẹ mi dá.

22 Bí a kò ti ṣe lè ka iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí a kò sì lè wọn yanrìn etí òkun, bẹ́ẹ̀ ní n óo ṣe sọ arọmọdọmọ Dafidi ati arọmọdọmọ Lefi alufaa, iranṣẹ mi, di pupọ.”

23 OLUWA bi Jeremaya pé:

24 “Ṣé o kò gbọ́ ohun tí àwọn eniyan wọnyi ń sọ tí wọn ní, ‘OLUWA ti kọ ìdílé mejeeji tí ó yàn sílẹ̀?’ Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń fojú tẹmbẹlu àwọn eniyan mi, títí tí wọn kò fi dàbí orílẹ̀-èdè lójú wọn mọ́.

25 Bí n kò bá tíì fìdí majẹmu mi múlẹ̀ pẹlu ọ̀sán ati òru, tí n kò sì ṣe ìlànà fún ọ̀run ati ayé,

26 òun nìkan ni n óo fi kọ arọmọdọmọ Jakọbu ati Dafidi, iranṣẹ mi sílẹ̀, tí n kò fi ní máa yan ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹ̀ láti jọba lórí ìran Abrahamu, Isaaki ati Jakọbu. N óo dá ire wọn pada, n óo sì ṣàánú fún wọn.”

34

1 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA bá Jeremaya sọ nìyí, nígbà tí Nebukadinesari, ọba Babiloni, ati gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀, ati gbogbo ìjọba ayé tí wọ́n wà lábẹ́ rẹ̀, ati gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbógun ti Jerusalẹmu ati gbogbo àwọn ìlú Juda.

2 OLUWA, Ọlọrun Israẹli ní, kí n lọ sọ fún Sedekaya, ọba Juda pé òun OLUWA ní, “Mo ṣetán tí n óo fi ìlú yìí lé ọba Babiloni lọ́wọ́; yóo sì dáná sun ún.

3 Sedekaya, o kò ní sá àsálà, ṣugbọn wọn óo mú ọ, wọn óo fà ọ́ lé Nebukadinesari lọ́wọ́, ẹ óo rí ara yín lojukooju, ẹ óo bá ara yín sọ̀rọ̀, o óo sì lọ sí Babiloni.

4 Sibẹsibẹ, ìwọ Sedekaya, ọba Juda OLUWA ní wọn kò ní fi idà pa ọ́.

5 O óo fi ọwọ́ rọrí kú ni. Bí wọn ti sun turari níbi òkú àwọn baba rẹ, ati níbi òkú àwọn ọba tí wọ́n ti kú ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóo sun turari níbi òkú ìwọ náà. Wọn yóo dárò rẹ, wọn yóo máa wí pé, ‘Ó ṣe, oluwa mi,’ nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni èmi OLUWA ṣe ìlérí; èmi ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

6 Jeremaya wolii bá sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà fún Sedekaya ọba Juda, ní Jerusalẹmu,

7 ní àkókò tí àwọn ọmọ ogun ọba Babiloni gbógun ti Jerusalẹmu ati Lakiṣi ati Aseka, nítorí pé àwọn nìkan ni wọ́n ṣẹ́kù ninu àwọn ìlú olódi Juda.

8 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tí Sedekaya ọba ti bá gbogbo àwọn eniyan tí wọ́n wà ní Jerusalẹmu dá majẹmu pé kí wọn kéde ìdásílẹ̀,

9 kí olukuluku dá ẹrú rẹ̀, lọkunrin ati lobinrin, tí wọ́n jẹ́ Heberu sílẹ̀, kí wọn máa lọ ní òmìnira; kí ẹnikẹ́ni má sì fi Juu arakunrin rẹ̀ ṣe ẹrú mọ́.

10 Gbogbo àwọn ìjòyè ati àwọn ará ìlú tí wọ́n dá majẹmu yìí ni wọ́n gbọ́ràn, tí wọ́n sì dá àwọn ẹrú wọn lọkunrin ati lobinrin sílẹ̀; wọn kò sì fi wọ́n ṣe ẹrú mọ́.

11 Ṣugbọn nígbà tó yá, wọ́n yí ọ̀rọ̀ pada, wọ́n tún mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀, lọkunrin ati lobinrin, wọ́n tún fi ipá sọ wọ́n di ẹrú.

12 OLUWA wá sọ fún Jeremaya pé,

13 “Èmi OLUWA Ọlọrun Israẹli bá àwọn baba ńlá yín dá majẹmu nígbà tí mo kó wọn jáde kúrò lóko ẹrú ní ilẹ̀ Ijipti, mo ní,

14 lẹ́yìn ọdún meje, kí olukuluku yín máa dá ọmọ Heberu tí ó bá fi owó rà lẹ́rú sílẹ̀, lẹ́yìn tí ó bá ti sin oluwa rẹ̀ fún ọdún mẹfa. Mo ní ẹ gbọdọ̀ dá ẹrú náà sílẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ó máa lọ ní òmìnira, ṣugbọn àwọn baba ńlá yín kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu.

15 Láìpẹ́ yìí, ẹ ronupiwada, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi; ẹ kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn arakunrin yín. Ẹ dá majẹmu níwájú mi ninu ilé tí à ń fi orúkọ mi pè.

16 Ṣugbọn ẹ tún yí ọ̀rọ̀ pada, ẹ ba orúkọ mi jẹ́ nípa pé olukuluku yín, ẹ tún mú ẹrukunrin ati ẹrubinrin tí ẹ dá sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn yín, ẹ sì tún sọ wọ́n di ẹrú pada.

17 Nítorí náà ẹ kò gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu pé kí olukuluku kéde òmìnira fún arakunrin rẹ̀ ati ọmọnikeji rẹ̀. Ẹ wò ó! N óo kéde òmìnira fun yín: òmìnira sí ọwọ́ ogun, àjàkálẹ̀ àrùn ati ìyàn, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo sì fi yín ṣe ẹrú fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.

18 Àwọn ọkunrin tí wọn bá rú òfin mi, tí wọn kò sì tẹ̀lé ìlànà majẹmu tí wọn dá níwájú mi, n óo bẹ́ wọn bíi ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù tí wọn bẹ́ sí meji, tí wọ́n sì gba ààrin rẹ̀ kọjá.

19 Bí àwọn ìjòyè Juda ati àwọn ìjòyè Jerusalẹmu, àwọn ìwẹ̀fà, àwọn alufaa ati gbogbo àwọn eniyan ilẹ̀ náà ṣe bẹ́ ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù sí meji, tí wọn sì gba ààrin rẹ̀ kọjá láti bá mi dá majẹmu, ni n óo ṣe bẹ́ àwọn náà.

20 N óo fà wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́ ati àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí wọn; òkú wọn yóo di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ati àwọn ẹranko.

21 N óo fi Sedekaya, ọba Juda ati àwọn ìjòyè rẹ̀ lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́ ati àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí wọn. Wọn óo bọ́ sọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun ọba Babiloni tí ó ti ṣígun kúrò lọ́dọ̀ wọn.

22 Ẹ wò ó, n óo pàṣẹ, n óo sì kó wọn pada sí ìlú yìí, wọn yóo gbógun tì í, wọn yóo gbà á; wọn yóo sì dáná sun ún. N óo sọ àwọn ìlú Juda di ahoro, kò ní sí eniyan tí yóo máa gbé inú wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

35

1 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ ní ìgbà ayé Jehoiakimu ọmọ Josaya, ọba Juda; ó ní,

2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu kí o bá wọn sọ̀rọ̀, mú wọn wá sinu ọ̀kan ninu àwọn yàrá tí ó wà ninu ilé OLUWA, kí o sì fi ọtí lọ̀ wọ́n.”

3 Mo bá mú Jaasanaya ọmọ Jeremaya ọmọ Habasinaya ati àwọn arakunrin rẹ̀ ati gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ ati gbogbo ìdílé Rekabu,

4 mo mú wọn wá sinu ilé OLUWA. Mo kó wọn lọ sinu yàrá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Hanani, ọmọ Igidalaya eniyan Ọlọrun, yàrá náà wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ yàrá àwọn ìjòyè, lókè yàrá Maaseaya ọmọ Ṣalumu, aṣọ́nà.

5 Mo gbé ìgò ọtí kalẹ̀ níwájú àwọn ọmọ Rekabu, mo kó ife tì í. Mo bá sọ fún wọn pé, “Ó yá, ẹ máa mu ọtí waini.”

6 Ṣugbọn wọ́n dáhùn pé, “A kò ní mu ọtí kankan nítorí pé Jonadabu, baba ńlá wa tíí ṣe ọmọ Rekabu ti pàṣẹ fún wa pé a kò gbọdọ̀ mu ọtí, ati àwa ati arọmọdọmọ wa títí lae.

7 A kò gbọdọ̀ kọ́ ilé, a kò gbọdọ̀ dá oko, a kò gbọdọ̀ gbin ọgbà àjàrà. Ó ní inú àgọ́ ni kí á máa gbé ní gbogbo ọjọ́ ayé wa, kí ọjọ́ wa baà lè pẹ́ lórí ilẹ̀ tí à ń gbé.

8 A gbọ́ràn sí Jonadabu baba ńlá wa lẹ́nu, à ń pa gbogbo àṣẹ tí ó pa fún wa mọ́, pé kí á má mu ọtí ní gbogbo ọjọ́ ayé wa, àwa, àwọn aya wa ati àwọn ọmọ wa lọkunrin ati lobinrin.

9 Ó ní a kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tí a óo máa gbé. A kò ṣe ọgbà àjàrà, tabi kí á dá oko, tabi kí á gbin ohun ọ̀gbìn.

10 Inú àgọ́ ni à ń gbé, a sì pa gbogbo àṣẹ tí Jonadabu baba ńlá wa fún wa mọ́.

11 Ṣugbọn nígbà tí Nebukadinesari, ọba Babiloni gbógun ti ilẹ̀ yìí, a wí fún ara wa pé kí á wá sí Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù àwọn ọmọ ogun, àwọn ará Kalidea ati ti àwọn ará Siria. Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe di ẹni tí ń gbé Jerusalẹmu.”

12 OLUWA bá sọ fún Jeremaya pé,

13 “Èmi OLUWA, àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní kí o lọ sọ fún àwọn ará Juda ati àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu pé, ṣé wọn kò ní gba ẹ̀kọ́ kí wọn sì fetí sí ọ̀rọ̀ mi ni?

14 Àwọn ọmọ Rekabu pa òfin tí Jonadabu, baba ńlá wọn, fún wọn mọ́, pé kí wọn má mu ọtí waini, wọn kò sì mu ọtí rárá títí di òní olónìí, nítorí pé wọ́n pa àṣẹ baba ńlá wọn mọ́. Mo ti bá yín sọ̀rọ̀ ní ọpọlọpọ ìgbà, ṣugbọn ẹ kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu.

15 Mo ti rán gbogbo àwọn iranṣẹ mi, àwọn wolii, si yín, ní ọpọlọpọ ìgbà pé kí olukuluku yín yipada kúrò ní ọ̀nà burúkú tí ó ń tọ̀, kí ẹ tún ìwà yín ṣe, kí ẹ má sá tẹ̀lé àwọn oriṣa kiri, kí ẹ yé máa sìn wọ́n; kí ẹ lè máa gbé ilẹ̀ tí mo fún ẹ̀yin ati àwọn baba ńlá yín. Ṣugbọn ẹ kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi, ẹ kò sì gbọ́ràn sí mi lẹ́nu.

16 Àwọn ọmọ Jonadabu, ọmọ Rekabu mú àṣẹ baba ńlá wọn tí ó pa fún wọn ṣẹ, ṣugbọn àwọn eniyan wọnyi kò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu.

17 Nítorí náà, èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli, ni mo sọ pé n óo jẹ́ kí ibi bá àwọn ará Juda ati àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu, nítorí pé mo bá wọn sọ̀rọ̀, wọn kò gbọ́; mo pè wọ́n, wọn kò dáhùn.”

18 Ṣugbọn Jeremaya sọ fún àwọn ọmọ Rekabu pé, “OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘Nítorí pé ẹ gbọ́ràn sí Jonadabu baba ńlá yín lẹ́nu, ẹ sì pa gbogbo òfin rẹ̀ mọ́, ẹ sì ń ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ pé kí ẹ máa ṣe,

19 nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní títí lae, kò ní sí ìgbà kan tí Jonadabu, ọmọ Rekabu kò ní ní ẹnìkan tí yóo máa ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú mi.’ ”

36

1 Ní ọdún kẹrin ìjọba Jehoiakimu ọmọ Josaya ọba Juda, OLUWA sọ fún Jeremaya pé,

2 “Mú ìwé kíká kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún ọ nípa Israẹli ati Juda ati gbogbo orílẹ̀-èdè sinu rẹ̀. Gbogbo ohun tí mo sọ láti ọjọ́ tí mo ti ń bá ọ sọ̀rọ̀ ní ìgbà ayé Josaya títí di òní, ni kí o kọ.

3 Bóyá bí àwọn ará Juda bá gbọ́ nípa ibi tí mò ń gbèrò láti ṣe sí wọn, olukuluku lè yipada kúrò ninu ọ̀nà ibi rẹ̀, kí n lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ ati àìdára wọn jì wọ́n.”

4 Jeremaya bá pe Baruku ọmọ Neraya, ó sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí OLUWA bá a sọ fún un, Baruku bá kọ wọ́n sinu ìwé kíká kan.

5 Jeremaya pàṣẹ fún Baruku pé, “Wọn kò gbà mí láàyè láti lọ sí inú ilé OLUWA;

6 nítorí náà, ìwọ ni óo lọ sibẹ ní ọjọ́ ààwẹ̀ láti ka ọ̀rọ̀ tí o gbọ́ ní ẹnu mi; tí o sì kọ sí inú ìwé kíká, sí etí gbogbo àwọn ará Juda tí wọ́n wá láti ìlú wọn.

7 Ó ṣeéṣe kí wọn mú ẹ̀bẹ̀ wọn wá siwaju OLUWA, kí olukuluku sì yipada kúrò lọ́nà ibi rẹ̀ tí ó ń rìn, nítorí pé ibinu OLUWA pọ̀ lórí wọn.”

8 Baruku bá ṣe gbogbo ohun tí Jeremaya wolii pa láṣẹ fún un lati kà lati inú ìwé ilé Oluwa.

9 Ní oṣù kẹsan-an, ọdún karun-un tí Jehoiakimu ọmọ Josaya jọba ní Juda, gbogbo àwọn tí wọn ń gbé Jerusalẹmu ati àwọn eniyan tí wọ́n ti àwọn ìlú Juda wá sí Jerusalẹmu, kéde ọjọ́ ààwẹ̀ níwájú OLUWA.

10 Baruku bá ka ọ̀rọ̀ Jeremaya tí ó kọ sinu ìwé, sí etígbọ̀ọ́ gbogbo eniyan ní yàrá Gemaraya, ọmọ Ṣafani, akọ̀wé, tí ó wà ní gbọ̀ngàn òkè ní Ẹnu Ọ̀nà Titun ilé OLUWA.

11 Nígbà tí Mikaaya ọmọ Gemaraya, ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ OLUWA tí ó wà ninu ìwé náà;

12 Ó lọ sí yàrá akọ̀wé ní ààfin ọba, ó bá gbogbo àwọn ìjòyè tí wọn jókòó níbẹ̀: Eliṣama akọ̀wé ati Delaaya ọmọ Ṣemaaya, ati Elinatani ọmọ Akibori, ati Gemaraya ọmọ Ṣafani, ati Sedekaya ọmọ Hananaya ati gbogbo àwọn ìjòyè.

13 Mikaaya sọ gbogbo ohun tí ó gbọ́, nígbà tí Baruku ka ohun tí ó kọ sinu ìwé fún wọn.

14 Gbogbo àwọn ìjòyè bá rán Jehudi ọmọ Netanaya, ọmọ Ṣelemaya ọmọ Kuṣi pé kí ó lọ sọ fún Baruku kí ó máa bọ̀ kí ó sì mú ìwé tí ó kà sí etígbọ̀ọ́ gbogbo eniyan lọ́wọ́. Baruku, ọmọ Neraya, sì wá sọ́dọ̀ wọn tòun ti ìwé náà lọ́wọ́ rẹ̀.

15 Wọ́n ní kí ó jókòó, kí ó kà á fún àwọn, Baruku bá kà á fún wọn.

16 Nígbà tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà, ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí wo ara wọn lójú. Wọ́n bá sọ fún Baruku pé, “A gbọdọ̀ sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún ọba.”

17 Wọ́n bi Baruku pé, “Sọ fún wa, báwo ni o ṣe kọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọnyi sílẹ̀? Ṣé Jeremaya ni ó sọ ọ́, tí ìwọ fi ń kọ ọ́ ni, àbí báwo?”

18 Baruku bá dá wọn lóhùn pé, Jeremaya ni ó sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà fún òun ni òun fi kọ ọ́ sinu ìwé.

19 Àwọn ìjòyè bá sọ fún Baruku pé kí òun ati Jeremaya lọ sápamọ́, kí wọn má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ ibi tí wọ́n wà.

20 Àwọn ìjòyè bá fi ìwé náà pamọ́ sinu yàrá Eliṣama akọ̀wé, lẹ́yìn náà wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní gbọ̀ngàn, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà fún un.

21 Ọba bá rán Jehudi pé kí ó lọ mú ìwé náà wá, ó sì mú un wá láti inú yàrá Eliṣama, akọ̀wé. Jehudi bá kà á fún ọba ati gbogbo àwọn ìjòyè tí wọn dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.

22 Ninu oṣù kẹsan-an ni ọ̀rọ̀ yìí ṣẹlẹ̀, ọba sì wà ní ilé tíí máa gbé ní àkókò òtútù, iná kan sì wà níwájú rẹ̀ tí ń jó ninu agbada.

23 Bí Jehudi bá ti ka òpó mẹta tabi mẹrin ninu ìwé náà, ọba yóo fi ọ̀bẹ gé e kúrò, yóo sì jù ú sinu iná tí ń jó níwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe títí ó fi fi ìwé náà jóná tán.

24 Sibẹ ẹ̀rù kò ba ọba tabi àwọn iranṣẹ rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò sì fa aṣọ wọn ya.

25 Elinatani, Dilaaya ati Gemaraya tilẹ̀ bẹ ọba pé kí ó má fi ìwé náà jóná, ṣugbọn kò gbà.

26 Ọba bá pàṣẹ fún Jerameeli ọmọ rẹ̀, ati Seraaya ọmọ Asirieli, ati Ṣelemaya ọmọ Abideeli, pé kí wọn lọ mú Baruku akọ̀wé, ati Jeremaya wolii wá, ṣugbọn OLUWA fi wọ́n pamọ́.

27 Lẹ́yìn tí ọba ti fi ìwé náà jóná, ati gbogbo ohun tí Jeremaya ní kí Baruku kọ sinu rẹ̀, OLUWA sọ fún Jeremaya pé,

28 “Mú ìwé mìíràn kí o tún kọ gbogbo ohun tí ó wà ninu ìwé ti àkọ́kọ́, tí Jehoiakimu, ọba Juda fi jóná sinu rẹ̀.

29 Ohun tí o óo kọ nípa Jehoiakimu ọba Juda, nìyí: sọ pé èmi OLUWA ní, ṣé ó fi ìwé ti àkọ́kọ́ jóná ni, ó ní, kí ló dé tí a fi kọ sinu rẹ̀ pé dájúdájú, ọba Babiloni ń bọ̀ wá pa ilẹ̀ yìí run ati pé, yóo pa ati eniyan ati ẹranko tí ó wà ninu rẹ̀ run?

30 Nítorí náà, ohun tí èmi OLUWA níí sọ nípa rẹ̀ ni pé, ẹyọ ọmọ rẹ̀ kan kò ní jọba lórí ìtẹ́ Dafidi. Ìta ni a óo gbé òkú rẹ̀ jù sí, oòrùn yóo máa pa á lọ́sàn-án, ìrì yóo sì máa sẹ̀ sí i lórí lóru.

31 N óo jẹ òun, ati àwọn ọmọ rẹ̀, ati àwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀ níyà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. N óo mú kí gbogbo ibi tí mo pinnu lórí wọn ṣẹ sí wọn lára ati sí ara àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu ati àwọn ará Juda, nítorí pé wọn kò gbọ́ràn.”

32 Jeremaya bá fún Baruku akọ̀wé, ọmọ Neraya, ní ìwé mìíràn, Baruku sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Jeremaya sọ fún un sinu rẹ̀. Ó kọ ohun tí ó wà ninu ìwé àkọ́kọ́ tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná, ó sì fi àwọn nǹkan mìíràn kún un pẹlu.

37

1 Nebukadinesari, ọba Babiloni fi Sedekaya, ọmọ Josaya, jọba ní ilẹ̀ Juda dípò Jehoiakini, ọmọ Jehoiakimu.

2 Ṣugbọn Sedekaya ati àwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀ ati àwọn eniyan náà kò pa ọ̀rọ̀ tí OLUWA ní kí Jeremaya wolii sọ fún wọn mọ́.

3 Ọba Sedekaya rán Jehukali, ọmọ Ṣelemaya, ati Sefanaya, alufaa, ọmọ Maaseaya, sí Jeremaya wolii, pé kí ó jọ̀wọ́ bá àwọn gba adura sí OLUWA Ọlọrun.

4 Ní àkókò yìí Jeremaya sì ń rìn káàkiri láàrin àwọn eniyan, nítorí wọn kò tíì jù ú sẹ́wọ̀n nígbà náà.

5 Àwọn ọmọ ogun Farao ti jáde, wọ́n ń bọ̀ láti Ijipti; nígbà tí àwọn ará Kalidea tí wọn dóti Jerusalẹmu gbọ́ pé wọ́n ń bọ̀, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.

6 OLUWA sọ fún Jeremaya wolii pé kí ó sọ fún àwọn tí ọba Juda rán láti wá wádìí ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀ pé,

7 OLUWA Ọlọrun Israẹli ní kí òun Jeremaya sọ fún ọba pé, àwọn ọmọ ogun Farao tí wọn wá ràn wọ́n lọ́wọ́ ti ń múra láti pada sí Ijipti, ilẹ̀ wọn.

8 Àwọn ará Kalidea sì ń pada bọ̀ wá gbé ogun ti ìlú yìí; wọn yóo gbà á, wọn yóo sì dáná sun ún.

9 OLUWA ní kí wọn sọ fún Sedekaya ati àwọn ará Juda kí wọn má tan ara wọn jẹ, kí wọn má sì rò pé àwọn ará Kalidea kò ní pada wá sọ́dọ̀ wọn mọ́, nítorí wọn kò ní lọ.

10 Bí àwọn ará Juda bá tilẹ̀ ṣẹgun gbogbo ọmọ ogun àwọn ará Kalidea, tí wọ́n gbógun tì wọ́n, títí tí ó fi jẹ́ pé àwọn tí wọ́n ti fara gbọgbẹ́ nìkan ni wọ́n kù ninu àgọ́ wọn, wọn yóo dìde sí àwọn ará Juda, wọn yóo sì sun ìlú yìí níná.

11 Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ ogun Kalidea ti kúrò ní Jerusalẹmu, nígbà tí wọ́n rí i pé àwọn ọmọ ogun Farao ń bọ̀,

12 Jeremaya jáde ní Jerusalẹmu ó fẹ́ lọ sí ilẹ̀ Bẹnjamini kí ó lọ gba ilẹ̀ rẹ̀ kan lọ́wọ́ àwọn eniyan tí wọ́n wà níbẹ̀.

13 Bí Jeremaya wolii ti dé bodè Bẹnjamini ọ̀kan ninu àwọn oníbodè tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Irija ọmọ Ṣelemaya ọmọ Hananaya mú un, ó ní, “O fẹ́ sálọ bá àwọn ará Kalidea ni.”

14 Jeremaya dá a lóhùn, pé, “Rárá o, n kò sálọ sọ́dọ̀ àwọn ará Kalidea.” Ṣugbọn Irija kọ̀, kò gbọ́, ó sá mú Jeremaya lọ sọ́dọ̀ àwọn ìjòyè.

15 Inú bí àwọn ìjòyè sí Jeremaya, wọ́n lù ú, wọ́n sì jù ú sẹ́wọ̀n ní ilé Jonatani akọ̀wé, nítorí pé wọ́n ti sọ ibẹ̀ di ọgbà ẹ̀wọ̀n.

16 Lẹ́yìn tí Jeremaya ti wà ní ọgbà ẹ̀wọ̀n fún ọpọlọpọ ọjọ́,

17 Sedekaya ọba ranṣẹ lọ mú un wá sí ààfin rẹ̀, ó sì fi ọ̀rọ̀ wá a lẹ́nu wò níkọ̀kọ̀, ó ní, “Ǹjẹ́ OLUWA ranṣẹ kankan?” Jeremaya dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ ni, ohun tí OLUWA sọ ni pé, a óo fi ọ́ lé ọba Babiloni lọ́wọ́.”

18 Jeremaya wá bi Sedekaya ọba pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́, tabi àwọn ẹmẹ̀wà rẹ, tabi àwọn ará ìlú yìí, tí ẹ fi jù mí sẹ́wọ̀n?

19 Níbo ni àwọn wolii rẹ wà, àwọn tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ọ pé, ‘Ọba Babiloni kò ní gbógun ti ìwọ ati ilẹ̀ yìí?’

20 Nisinsinyii, kabiyesi, oluwa mi, jọ̀wọ́ fetí sí ẹ̀bẹ̀ mi, má dá mi pada sí ilé Jonatani akọ̀wé, kí n má baà kú sibẹ.”

21 Sedekaya ọba bá pàṣẹ, wọ́n sì fi Jeremaya sinu gbọ̀ngàn ọgbà àwọn tí ń ṣọ́ ààfin. Wọ́n sì ń fún un ní burẹdi kan lojumọ láti òpópónà àwọn oníburẹdi títí tí gbogbo burẹdi fi tán ní ìlú. Bẹ́ẹ̀ ni Jeremaya ṣe bẹ̀rẹ̀ sí gbé gbọ̀ngàn àwọn tí ń ṣọ́ ààfin.

38

1 Nígbà tí Ṣefataya, ọmọ Matani, ati Gedalaya, ọmọ Paṣuri, ati Jukali, ọmọ Ṣelemaya, ati Paṣuri ọmọ Malikaya gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Jeremaya ń sọ fún gbogbo àwọn eniyan pé,

2 “OLUWA ní, ẹni tí ó bá dúró ní ìlú Jerusalẹmu yóo kú ikú idà, ìyàn ati àjàkálẹ̀ àrùn; ṣugbọn àwọn tí wọn bá jáde tọ àwọn ará Kalidea lọ yóo yè. Ó ní ọ̀rọ̀ wọn yóo dàbí ẹni tí ó ja àjàbọ́, ṣugbọn yóo wà láàyè.

3 Ati pé dájúdájú, ìlú yìí yóo bọ́ sọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun Babiloni, wọn yóo sì gbà á.”

4 Àwọn ìjòyè náà bá sọ fún ọba pé, “Ẹ jẹ́ kí á pa ọkunrin yìí nítorí pé ó ń mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ ogun tí wọn kù láàrin ìlú, ati gbogbo àwọn eniyan nítorí irú ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ fún wọn. Ọkunrin yìí kò fẹ́ alaafia àwọn eniyan wọnyi, àfi ìpalára wọn.”

5 Sedekaya ọba bá dá wọn lóhùn, pé, “Ìkáwọ́ yín ló wà, n kò jẹ́ ṣe ohunkohun tí ó bá lòdì sí ìfẹ́ yín.”

6 Wọ́n bá mú Jeremaya, wọ́n jù ú sinu kànga Malikaya, ọmọ ọba, tí ó wà ní gbọ̀ngàn àwọn tí wọn ń ṣọ́ ààfin. Wọ́n fi okùn sọ Jeremaya kalẹ̀ sinu kànga náà, kò sí omi ninu rẹ̀, àfi ẹrẹ̀ nìkan, Jeremaya sì rì sinu ẹrẹ̀ náà.

7 Nígbà tí Ebedimeleki ará Etiopia tí ó jẹ́ ìwẹ̀fà ní ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremaya sinu kànga. Ọba wà níbi tí ó jókòó sí ní ibodè Bẹnjamini.

8 Ebedimeleki jáde ní ààfin, ó lọ bá ọba ó sì wí fún un pé,

9 “Kabiyesi, oluwa mi, gbogbo nǹkan tí àwọn eniyan wọnyi ṣe sí wolii Jeremaya kò dára. Inú kànga ni wọ́n jù ú sí, ebi ni yóo sì pa á sibẹ nítorí pé kò sí burẹdi ní ìlú mọ́.”

10 Ọba bá pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Etiopia, ó ní, “Mú eniyan mẹta lọ́wọ́, kí ẹ lọ yọ Jeremaya wolii kúrò ninu kànga náà kí ó tó kú.”

11 Ebedimeleki bá mú àwọn ọkunrin mẹta náà, wọ́n lọ sí yàrá kan ní ilé ìṣúra tí ó wà láàfin ọba. Ó mú àwọn àkísà ati àwọn aṣọ tí wọ́n ti gbó níbẹ̀, ó so okùn mọ́ wọn, ó sì nà án sí Jeremaya ninu kànga.

12 Ó bá sọ fún Jeremaya pé kí ó fi àwọn àkísà ati àwọn aṣọ tí wọ́n ti gbó náà sí abíyá mejeeji, kí ó fi okùn kọ́ ara rẹ̀ lábíyá. Jeremaya sì ṣe bẹ́ẹ̀.

13 Wọ́n bá fi okùn fa Jeremaya jáde kúrò ninu kànga. Jeremaya bá ń gbé gbọ̀ngàn àwọn tí wọn ń ṣọ́ ààfin.

14 Sedekaya ọba ranṣẹ lọ mú Jeremaya wolii wá sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ẹnu ọ̀nà kẹta tí ó wà ní Tẹmpili OLUWA, ó wí fún Jeremaya pé, “Ọ̀rọ̀ kan ni mo fẹ́ bèèrè lọ́wọ́ rẹ, má sì fi ohunkohun pamọ́ fún mi.”

15 Jeremaya bá wí fún Sedekaya, ó ní, “Bí mo bá sọ fún ọ, o kò ní pa mí dájúdájú? Bí mo bá sì fún ọ ní ìmọ̀ràn, o kò ní gbà.”

16 Sedekaya ọba bá búra fún Jeremaya ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Mo fi OLUWA alààyè ẹni tí ó dá ẹ̀mí wa búra, pé n kò ní pa ọ́, n kò sì ní fi ọ́ lé àwọn tí wọn ń wá ọ̀nà láti pa ọ́ lọ́wọ́.”

17 Jeremaya bá wí fún Sedekaya pé, “OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babiloni, wọn ó dá ẹ̀mí rẹ sí, wọn kò sì ní dáná sun ìlú yìí, ìwọ ati àwọn ará ilé rẹ yóo sì yè.

18 Ṣugbọn bí o kò bá fi ara rẹ le àwọn ìjòyè ọba Babiloni lọ́wọ́, ìlú yìí yóo bọ́ sọ́wọ́ àwọn ará Kalidea, wọn yóo sì dáná sun ún, ìwọ pàápàá kò sì ní bọ́ lọ́wọ́ wọn.”

19 Sedekaya ọba bá wí fún Jeremaya pé, “Ẹ̀rù àwọn ará Juda tí wọ́n sá lọ bá àwọn ará Kalidea ń bà mí. Wọ́n lè fà mí lé wọn lọ́wọ́, kí wọ́n sì fi mí ṣẹ̀sín.”

20 Jeremaya dáhùn pé, “Wọn kò ní fà ọ́ lé wọn lọ́wọ́. Tẹ̀lé ọ̀rọ̀ OLUWA tí mò ń sọ fún ọ; yóo dára fún ọ, a óo sì dá ẹ̀mí rẹ sí.

21 Ṣugbọn bí o bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ ohun tí OLUWA fihàn mí nìyí:

22 Wò ó, mo rí i tí wọn ń kó àwọn obinrin tí wọ́n wà ní ààfin ọba Juda jáde lọ sọ́dọ̀ àwọn ìjòyè ọba Babiloni, wọ́n sì ń wí pé, ‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí o fọkàn tán tàn ọ́, wọ́n sì ti ṣẹgun rẹ; nisinsinyii tí o rì sinu ẹrẹ̀, wọ́n pada lẹ́yìn rẹ.’

23 “Gbogbo àwọn aya rẹ ati àwọn ọmọ rẹ ni wọn yóo kó lọ sọ́dọ̀ àwọn ará Kalidea, ìwọ gan-an kò sì ní bọ́ lọ́wọ́ wọn. Ọwọ́ ọba Babiloni yóo tẹ̀ ọ́, wọn yóo sì dáná sun ìlú yìí.”

24 Sedekaya ọba bá kìlọ̀ fún Jeremaya pé, “Má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ gbogbo nǹkan tí a jọ sọ, o kò sì ní kú.

25 Bí àwọn ìjòyè bá gbọ́ pé a jọ sọ̀rọ̀, bí wọn bá wá sọ́dọ̀ rẹ tí wọn ní kí o sọ nǹkan tí o bá mi sọ fún àwọn, ati èsì tí mo fún ọ, tí wọn bẹ̀ ọ́ pé kí o má fi ohunkohun pamọ́ fún àwọn, tí wọn sì ṣe ìlérí pé àwọn kò ní pa ọ́,

26 sọ fún wọn pé ẹ̀bẹ̀ ni ò ń bẹ̀ mí pé kí n má dá ọ pada sí ilé Jonatani; kí o má baà kú sibẹ.”

27 Gbogbo àwọn ìjòyè tọ Jeremaya lọ, wọ́n bí í, ó sì fún wọn lésì gẹ́gẹ́ bí ọba tí pàṣẹ fún un. Wọ́n bá dákẹ́, nítorí ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ tí wọ́n jọ sọ.

28 Jeremaya bá ń gbé gbọ̀ngàn àwọn tí wọn ń ṣọ́ ààfin títí di ọjọ́ tí ogun kó Jerusalẹmu.

39

1 Ní oṣù kẹwaa, ọdún kẹsan-an ìjọba Sedekaya, ọba Juda, Nebukadinesari, ọba Babiloni, ati àwọn ọmọ ogun rẹ̀ gbógun ti Jerusalẹmu, wọ́n sì dótì í.

2 Ní ọjọ́ kẹsan-an, oṣù kẹrin, ọdún kọkanla ìjọba rẹ̀, wọ́n wọ ìlú náà.

3 Lẹ́yìn tí ogun ti kó Jerusalẹmu, gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babiloni péjọ, wọ́n sì jókòó ní bodè ààrin: Negali Sareseri, Samgari Nebo, Sarisekimu Rabusarisi, Negali Sareseri, Rabumagi ati àwọn ìjòyè ọba Babiloni yòókù.

4 Nígbà tí Sedekaya ọba Juda ati àwọn ọmọ ogun rẹ̀ rí wọn, wọ́n sá. Wọ́n fòru bojú, wọ́n bá jáde ní ìlú; wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba, ní ọ̀nà ibodè tí ó wà láàrin odi meji, wọ́n sì dojú kọ ọ̀nà Araba.

5 Ṣugbọn àwọn ọmọ ogun Kalidea lé wọn, wọ́n bá Sedekaya ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹriko; wọ́n mú un lọ sí ọ̀dọ̀ Nebukadinesari ọba Babiloni ní Ribila ní ilẹ̀ Hamati, ó sì dá Sedekaya lẹ́jọ́.

6 Ọba Babiloni pa àwọn ọmọ Sedekaya ní Ribila níṣojú rẹ̀, ó sì pa gbogbo àwọn ìjòyè Juda pẹlu.

7 Ó yọ ojú Sedekaya, ó sì fi ẹ̀wọ̀n bàbà dè é láti mú un lọ sí Babiloni.

8 Àwọn ará Kalidea jó ààfin ọba ati ilé àwọn ará ìlú, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu lulẹ̀.

9 Nebusaradani olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ bá kó àwọn eniyan tí wọn ṣẹ́kù ní Jerusalẹmu ní ìgbèkùn, lọ sí Babiloni pẹlu àwọn tí wọn kọ́ sá lọ bá a tẹ́lẹ̀.

10 Nebusaradani olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ fi díẹ̀ ninu àwọn talaka sílẹ̀ ní ilẹ̀ Juda, ó sì fún wọn ní ọgbà àjàrà ati oko.

11 Nebukadinesari ọba Babiloni pàṣẹ fún Nebusaradani olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ pé

12 kí wọn mú Jeremaya, kí wọn tọ́jú rẹ̀ dáradára, kí wọn má pa á lára, ṣugbọn kí wọn ṣe ohunkohun tí ó bá ń fẹ́ fún un.

13 Nebusaradani olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ ati Nebuṣasibani, ìjòyè pataki kan, ati Negali Sareseri olóyè pataki mìíràn ati gbogbo àwọn olóyè jàǹkànjàǹkàn ninu àwọn ìjòyè ọba Babiloni,

14 wọ́n ranṣẹ lọ mú Jeremaya jáde kúrò ní ìgbèkùn. Wọ́n bá fà á lé Gedalaya ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani lọ́wọ́, pé kí ó mú un lọ sí ilé rẹ̀. Ó bá ń gbé ààrin àwọn eniyan náà.

15 OLUWA sọ fún Jeremaya nígbà tí ó wà ní àtìmọ́lé ní gbọ̀ngàn àwọn tí wọn ń ṣọ́ ààfin ọba, pé,

16 kí ó lọ sọ fún Ebedimeleki ará Etiopia pé, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, “Wò ó, n óo mú ìpinnu ibi tí mo ṣe lórí ìlú yìí ṣẹ, lójú rẹ ni yóo sì ṣẹ.

17 N óo gbà ọ́ sílẹ̀ ní ọjọ́ náà, wọn kò ní fà ọ́ lé àwọn tí ò ń bẹ̀rù lọ́wọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

18 Nítorí pé, dájúdájú n óo gbà ọ́ sílẹ̀, o ò ní kú ikú idà, ṣugbọn o óo sá àsálà, nítorí pé o gbẹ́kẹ̀lé mi.”

40

1 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tí Nebusaradani, olórí àwọn tí ń ṣọ́ ọba Babiloni, tú u sílẹ̀ ní Rama. Nebusaradani rí Jeremaya tí wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é, wọ́n sì kó o pọ̀ mọ́ àwọn tí wọn kó kúrò ní ìlú Jerusalẹmu ati ní ilẹ̀ Juda tí wọn ń kó lọ sí Babiloni.

2 Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ ọba Babiloni, sọ fún Jeremaya pé, “OLUWA Ọlọrun rẹ ti pinnu láti ṣe ilẹ̀ yìí ní ibi;

3 Ó sì ti ṣe bí ó ti pinnu nítorí pé ẹ dẹ́ṣẹ̀ sí i, ẹ kò sì fetí sí ohùn rẹ̀, nítorí náà ni ibi ṣe dé ba yín.

4 Nisinsinyii, wò ó, mo tú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ ọwọ́ rẹ sílẹ̀, bí o bá fẹ́ bá mi lọ sí Babiloni, máa bá mi kálọ, n óo tọ́jú rẹ dáradára; bí o kò bá sì fẹ́ lọ, dúró. Wò ó, gbogbo ilẹ̀ nìyí níwájú rẹ yìí, ibi tí o bá fẹ́ tí ó dára lójú rẹ ni kí o lọ.

5 Bí o bá fẹ́ pada, pada lọ bá Gedalaya ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babiloni fi ṣe gomina àwọn ìlú Juda, kí o máa bá a gbé láàrin àwọn eniyan náà. Bí o kò bá sì fẹ́ bẹ́ẹ̀, ibi tí ó bá wù ọ́ láti lọ ni kí o lọ.” Olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ ọba bá fún un ní owó, oúnjẹ, ati ẹ̀bùn, ó ní kí ó máa lọ.

6 Jeremaya bá pada sọ́dọ̀ Gedalaya, ọmọ Ahikamu ní Misipa, ó sì ń gbé pẹlu rẹ̀ láàrin àwọn eniyan tí wọn kù ní ilẹ̀ náà.

7 Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà ní ìgbèríko pẹlu àwọn ọmọ ogun wọn gbọ́ pé ọba Babiloni ti fi Gedalaya ọmọ Ahikamu jẹ gomina ní ilẹ̀ Juda, ati pé ó ti fi ṣe olùtọ́jú àwọn ọkunrin, ati àwọn obinrin, ati àwọn ọmọde ati díẹ̀ ninu àwọn talaka ilẹ̀ Juda, tí wọn kò kó lọ sí Babiloni,

8 wọ́n lọ bá Gedalaya ní Misipa. Àwọn tí wọ́n lọ nìwọ̀nyí: Iṣimaeli, ọmọ Netanaya, Johanani, ọmọ Karea, Seraaya, ọmọ Tanhumeti, àwọn ọmọ Efai, ará Netofa, Jesanaya, ọmọ ará Maakati, àwọn àtàwọn eniyan wọn.

9 Gedalaya bá búra fún àwọn ati àwọn eniyan wọn pé, “Ẹ má bẹ̀rù ati sin àwọn ará Kalidea. Ẹ máa gbé ilẹ̀ yìí, kí ẹ máa sin ọba Babiloni, yóo sì dára fun yín.

10 Ní tèmi, Misipa ni n óo máa gbé kí n lè máa rí ààyè bá àwọn ará Kalidea tí wọn wá dótì wá sọ̀rọ̀. Ẹ̀yin ẹ máa kó ọtí, èso, ati òróró jọ sinu ìkòkò yín, kí ẹ sì máa gbé àwọn ìlú tí ẹ ti gbà.”

11 Bákan náà, nígbà tí gbogbo àwọn ará Juda tí wọn wà ní ilẹ̀ Moabu, ati àwọn tí wọn wà ní ilẹ̀ àwọn ará Amoni ati ti Edomu ati àwọn tí wọ́n wà ní gbogbo ilẹ̀ káàkiri gbọ́ pé ọba Babiloni dá àwọn eniyan díẹ̀ sí ní Juda, àtipé ó fi Gedalaya, ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani, ṣe gomina wọn,

12 gbogbo àwọn ará Juda pada láti gbogbo ibi tí wọn sá lọ, wọ́n wá sí ilẹ̀ Juda, wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Gedalaya ní Misipa, wọ́n sì kó ọtí ati èso jọ lọpọlọpọ.

13 Johanani ọmọ Karea ati gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà ní ìgbèríko wá sọ́dọ̀ Gedalaya ní Misipa.

14 Wọ́n sọ fún un pé, “Ǹjẹ́ o mọ̀ pé Baalisi, ọba àwọn ọmọ Amoni ti rán Iṣimaeli, ọmọ Netanaya pé kí ó wá pa ọ́?” Ṣugbọn Gedalaya kò gbà wọ́n gbọ́.

15 Johanani bá sọ fún Gedalaya ní ìkọ̀kọ̀ ní Misipa pé, “Jẹ́ kí n lọ pa Iṣimaeli ọmọ Netanaya, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ̀. Kí ló dé tí o óo jẹ́ kí ó pa ọ́, tí gbogbo Juda tí wọn kóra jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ yóo sì túká; tí àwọn tí wọn ṣẹ́kù ninu àwọn eniyan Juda yóo sì ṣègbé?”

16 Ṣugbọn Gedalaya sọ fún Johanani, ọmọ Karea pé, “Má ṣe bẹ́ẹ̀, irọ́ ni ò ń pamọ́ Iṣimaeli.”

41

1 Ní oṣù keje ni Iṣimaeli, ọmọ Netanaya ọmọ Eliṣama dé, ìdílé ọba ni ó ti wá, ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ọba. Òun pẹlu àwọn ọkunrin mẹ́wàá bá lọ sọ́dọ̀ Gedalaya ọmọ Ahikamu ní Misipa. Bí wọ́n ṣe ń jẹun lọ́wọ́ ní Misipa,

2 Iṣimaeli, ọmọ Netanaya ati àwọn mẹ́wàá tí wọ́n bá a wá dìde, wọ́n bá fi idà pa Gedalaya tí ọba Babiloni fi ṣe gomina ilẹ̀ náà.

3 Iṣimaeli pa gbogbo àwọn Juu tí wọ́n wà pẹlu Gedalaya ní Misipa, ati gbogbo àwọn ọmọ ogun Kalidea tí wọ́n wà níbẹ̀.

4 Ọjọ́ keji tí wọ́n pa Gedalaya tán, kí ẹnikẹ́ni tó gbọ́ nípa rẹ̀,

5 àwọn ọgọrin eniyan kan wá láti Ṣekemu, Ṣilo ati láti Samaria pẹlu irùngbọ̀n wọn ní fífá, wọ́n fa agbádá wọn ya, wọ́n sì ṣá ara wọn lọ́gbẹ́. Wọ́n mú ọrẹ ẹbọ ati turari lọ́wọ́ wá sí Tẹmpili OLUWA.

6 Iṣimaeli, ọmọ Netanaya sọkún pàdé wọn láti Misipa. Bí ó ti pàdé wọn ó wí pé, “Ẹ máa kálọ sí ọ̀dọ̀ Gedalaya ọmọ Ahikamu.”

7 Nígbà tí wọ́n wọ ààrin ìlú, Iṣimaeli ọmọ Netanaya ati àwọn tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì kó òkú wọn dà sí inú kòtò.

8 Ṣugbọn àwọn mẹ́wàá kan ninu wọn sọ fún Iṣimaeli pé, “Má pa wá, nítorí a ní ọkà wíítì, ọkà baali, ati òróró ati oyin ní ìpamọ́ ninu oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀ kò sì pa wọ́n bí ó ti pa àwọn yòókù wọn.

9 Kòtò tí Iṣimaeli ju òkú àwọn eniyan tí ó pa sí ni kòtò tí ọba Asa gbẹ́ tí ó fi dí ọ̀nà mọ́ Baaṣa ọba Israẹli; ṣugbọn Iṣimaeli, ọmọ Netanaya fi òkú eniyan tí ó pa kún kòtò náà.

10 Iṣimaeli bá kó gbogbo àwọn tí wọ́n kù ní Misipa lẹ́rú, àwọn ọmọ ọba lobinrin ati gbogbo àwọn tí wọ́n kù ní Misipa, àwọn tí Nebusaradani olórí àwọn tí wọn ń ṣọ́ ọba fi sí abẹ́ ìṣọ́ Gedalaya. Iṣimaeli kó wọn lẹ́rú ó sì fẹ́ kó wọn kọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn ará Amoni.

11 Nígbà tí Johanani, ọmọ Karea ati gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀ gbọ́ gbogbo iṣẹ́ ibi tí Iṣimaeli, ọmọ Netanaya ṣe,

12 wọ́n kó gbogbo àwọn ọmọ ogun wọn lọ gbógun ti Iṣimaeli, wọ́n bá a létí odò ńlá tí ó wà ní Gibeoni.

13 Nígbà tí gbogbo àwọn eniyan tí wọ́n wà lọ́dọ̀ Iṣimaeli rí Johanani, ọmọ Karea ati gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀, inú wọn dùn.

14 Ni gbogbo àwọn tí Iṣimaeli kó lẹ́rú ní Misipa bá yipada kúrò lẹ́yìn rẹ̀, wọ́n lọ bá Johanani ọmọ Karea.

15 Ṣugbọn Iṣimaeli, ọmọ Netanaya, pẹlu àwọn mẹjọ sá àsálà lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Amoni.

16 Lẹ́yìn náà Johanani ọmọ Karea, ati gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀, kó gbogbo àwọn tí Iṣimaeli ọmọ Netanaya kó lẹ́rú ní Misipa, lẹ́yìn tí ó pa Gedalaya ọmọ Ahikamu tán, ó bá kó ati àwọn ọmọ ogun, ati àwọn obinrin, ati àwọn ọmọde, ati àwọn ìwẹ̀fà, pada wá láti Gibeoni.

17 Wọ́n lọ ń gbé Geruti Kimhamu, tí ó wà lẹ́bàá Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n pinnu láti kó lọ sí ilẹ̀ Ijipti nítorí ẹ̀rù àwọn ará Kalidea ń bà wọ́n;

18 nítorí pé Iṣimaeli ọmọ Netanaya ti pa Gedalaya, ọmọ Ahikamu, tí ọba Babiloni fi ṣe gomina ilẹ̀ náà.

42

1 Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn olórí ogun ati Johanani, ọmọ Karea ati Asaraya, ọmọ Hoṣaaya, ati gbogbo àwọn ará Juda, lọ́mọdé ati lágbà, tọ wolii Jeremaya lọ.

2 Wọ́n wí fún un pé, “Nǹkan kan ni a fẹ́ bẹ̀ ọ́ fún, a sì fẹ́ kí o ṣe é fún wa: jọ̀wọ́, gbadura sí OLUWA Ọlọrun rẹ fún àwa ati gbogbo àwọn tí wọ́n ṣẹ́kù, nítorí pé a ti pọ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣugbọn díẹ̀ ninu wa ni ó kù, bí ìwọ náà ti fi ojú ara rẹ rí i.

3 A fẹ́ kí OLUWA Ọlọrun rẹ lè fi ọ̀nà tí a óo gbà hàn wá, kí ó sọ ohun tí a óo ṣe fún wa.”

4 Wolii Jeremaya bá dá wọn lóhùn pé, “Mo gbọ́, n óo gbadura sí OLUWA Ọlọrun yín bí ẹ ti wí; gbogbo ìdáhùn tí OLUWA bá fún mi ni n óo sọ fun yín, n kò ní fi nǹkankan pamọ́.”

5 Wọ́n wí fún Jeremaya pé, “Kí OLUWA ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ ati òdodo bí a kò bá ṣe gbogbo nǹkan tí OLUWA Ọlọrun bá ní kí o sọ fún wa.

6 Ìbáà jẹ́ rere ni OLUWA Ọlọrun wa tí a rán ọ sí sọ, kì báà jẹ́ burúkú, a óo gbọ́ràn sí i lẹ́nu; kí ó lè dára fún wa; nítorí pé ti OLUWA Ọlọrun wa ni a óo gbọ́.”

7 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwaa, OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀.

8 Jeremaya bá pe Johanani, ọmọ Karea ati gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀, ati gbogbo àwọn eniyan, ati àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki.

9 Ó sọ fún wọn pé, “OLUWA Ọlọrun Israẹli, ẹni tí ẹ ní kí n gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ siwaju rẹ̀ ní,

10 ‘Bí ẹ bá dúró ní ilẹ̀ yìí, n óo kọ yín bí ilé, n kò sì ní wo yín lulẹ̀. N óo gbìn yín bí igi, n kò sì ní fà yín tu, nítorí mo ti yí ọkàn mi pada nípa ibi tí mo ṣe sí yín.

11 Ẹ má bẹ̀rù ọba Babiloni tí ẹrù rẹ̀ ń bà yín, ẹ má bẹ̀rù rẹ̀; èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀, nítorí pé mo wà pẹlu yín. N óo gbà yín là n óo sì yọ yín lọ́wọ́ rẹ̀.

12 N óo ṣàánú yín, n óo jẹ́ kí ó ṣàánú yín, kí ó sì jẹ́ kí ẹ máa gbé orí ilẹ̀ yín.’

13 “Bí ẹ bá wí pé ẹ kò ní dúró ní ilẹ̀ yìí, tí ẹ kò sì gbọ́ràn sí OLUWA Ọlọrun yín lẹ́nu;

14 bí ẹ bá ń wí pé, ‘Rárá o, a óo sá lọ sí ilẹ̀ Ijipti, níbi tí a kò ti ní gbúròó ogun tabi fèrè ogun, níbi tí ebi kò ti ní pa wá, a óo sì máa gbé ibẹ̀,’

15 ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ̀yin tí ẹ ṣẹ́kù ní Juda. OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘Bí ẹ bá gbójú lé àtilọ sí Ijipti, pé ẹ óo lọ máa gbé ibẹ̀, ogun tí ẹ̀ ń sá fún yóo bá yín níbẹ̀;

16 ìyàn tí ẹ̀ ń bẹ̀rù yóo tẹ̀lé yín lọ sí Ijipti; ebi tí ẹ páyà rẹ̀ yóo gbá tẹ̀lé yín, ibẹ̀ ni ẹ óo sì kú sí.

17 Gbogbo àwọn tí wọ́n bá gbójú lé àtilọ sí Ijipti láti máa gbé ibẹ̀ yóo kú ikú ogun, ati ti ìyàn pẹlu àjàkálẹ̀ àrùn, wọn kò ní ṣẹ́kù, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni wọn kò ní bọ́ ninu ibi tí n óo mú wá sórí wọn.’

18 “Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘Bí mo ti bínú sí àwọn ará Jerusalẹmu, tí inú mi sì ń ru sí wọn, bẹ́ẹ̀ ni n óo bínú si yín nígbà tí ẹ bá dé Ijipti. Ẹ óo di ẹni ègún, ẹni àríbẹ̀rù, ẹni ẹ̀gàn ati ẹni ẹ̀sín. Ẹ kò sì ní fojú kan ilẹ̀ yìí mọ́.’

19 “OLUWA ti sọ fún ẹ̀yin tí ẹ ṣẹ́kù ní Juda pé kí ẹ má lọ sí Ijipti. Ẹ mọ̀ dájúdájú pé mo kìlọ̀ fun yín lónìí

20 pé ẹ ti fi ẹ̀mí ara yín wéwu nítorí ìṣìnà yín. Nítorí pé nígbà tí ẹ rán mi sí OLUWA Ọlọrun yín pé kí n gbadura fun yín, gbogbo ohun tí OLUWA Ọlọrun yín bá wí ni kí n sọ fun yín, ẹ ní ẹ óo sì ṣe é.

21 Mo ti sọ ohun tí Ọlọrun wí fun yín lónìí, ṣugbọn ẹ kò tẹ̀lé ọ̀kan kan ninu ohun tí OLUWA Ọlọrun yín ní kí n sọ fun yín.

22 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájú pé ẹ óo kú ikú ogun, ati ti ìyàn pẹlu àjàkálẹ̀ àrùn, ní ibi tí ẹ fẹ́ lọ máa gbé.”

43

1 Nígbà tí Jeremaya parí gbogbo ọ̀rọ̀ tí OLUWA Ọlọrun wọn rán an sí gbogbo àwọn ará ìlú,

2 Asaraya, ọmọ Hoṣaaya, ati Johanani, ọmọ Karea, ati gbogbo àwọn ọkunrin aláfojúdi kan wí fún Jeremaya pé, “Irọ́ ni ò ń pa. OLUWA Ọlọrun wa kò rán ọ láti sọ fún wa pé kí á má lọ ṣe àtìpó ní Ijipti.

3 Baruku, ọmọ Neraya, ni ó fẹ́ mú wa kọlù ọ́, kí o lè fà wá lé àwọn ará Kalidea lọ́wọ́, kí wọ́n lè pa wá; tabi kí wọ́n kó wa lọ sí ìgbèkùn ní Babiloni.”

4 Nítorí náà Johanani, ọmọ Karea, ati gbogbo àwọn olórí ogun ati gbogbo àwọn ará ìlú kò gba ohun tí OLUWA sọ, pé kí wọ́n dúró ní ilẹ̀ Juda.

5 Kàkà bẹ́ẹ̀, Johanani, ọmọ Karea, ati gbogbo àwọn olórí ogun kó gbogbo àwọn ará Juda tí wọ́n ṣẹ́kù, tí wọ́n pada wá sí ilẹ̀ Juda láti oríṣìíríṣìí orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti sálọ:

6 àwọn ọkunrin ati àwọn obinrin, àwọn ọmọde, àwọn ìjòyè, ati gbogbo àwọn tí Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ ọba Babiloni, fi sábẹ́ àkóso Gedalaya ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani, ati Jeremaya wolii ati Baruku ọmọ Neraya.

7 Wọ́n kó wọn lọ sí ilẹ̀ Ijipti, nítorí wọn kò fetí sí ọ̀rọ̀ OLUWA Ọlọrun wọn. Wọ́n lọ títí tí wọ́n fi dé Tapanhesi.

8 OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀ ní Tapanhesi:

9 Ó ní, “Gbé òkúta ńláńlá lọ́wọ́, kí o bò wọ́n mọ́lẹ̀, níbi pèpéle tí ó wà lẹ́nu ọ̀nà ààfin Farao ní Tapanhesi, lójú àwọn ará Juda,

10 kí o sì wí fún wọn pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní òun óo lọ mú Nebukadinesari ọba Babiloni, iranṣẹ òun wá, yóo sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ka orí àwọn òkúta tí òun rì mọ́lẹ̀ yìí, Nebukadinesari yóo sì tẹ́ ìtẹ́ ọlá rẹ̀ sórí wọn.

11 Yóo wá kọlu ilẹ̀ Ijipti, yóo jẹ́ kí àjàkálẹ̀ àrùn pa àwọn tí yóo kú ikú àjàkálẹ̀ àrùn, yóo kó àwọn tí yóo lọ sí ìgbèkùn lọ sí ìgbèkùn, yóo sì fi idà pa àwọn tí yóo kú ikú idà.

12 Yóo dáná sun àwọn ilé àwọn oriṣa ilẹ̀ Ijipti; yóo jó wọn níná; yóo sì kó àwọn ará ìlú lọ sí ìgbèkùn; yóo fọ ilẹ̀ Ijipti mọ́ bí darandaran tíí ṣa eégbọn kúrò lára aṣọ rẹ̀, yóo sì jáde kúrò níbẹ̀ ní alaafia.

13 Yóo fọ́ àwọn òpó ilé oriṣa Heliopolisi tí ó wà ní ilẹ̀ Ijipti, yóo sì dáná sun àwọn ilé àwọn oriṣa ilẹ̀ Ijipti.”

44

1 Nǹkan tí Jeremaya gbọ́ nípa gbogbo àwọn Juu tí wọn ń gbé Migidoli ati Tapanhesi, ati Memfisi ati ilẹ̀ Patirosi ní ilẹ̀ Ijipti nìyí.

2 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, “Ẹ rí gbogbo ibi tí mo jẹ́ kí ó bá Jerusalẹmu ati gbogbo ìlú Juda. Ẹ wò wọ́n lónìí bí wọ́n ti di ahoro, tí kò sì sí eniyan ninu wọn,

3 nítorí ibi tí wọ́n ṣe, wọ́n mú mi bínú nítorí pé wọ́n sun turari sí àwọn oriṣa tí àwọn tabi àwọn baba wọn kò mọ̀ rí, wọ́n sì ń sìn wọ́n.

4 Sibẹsibẹ mo rán gbogbo àwọn iranṣẹ mi, àwọn wolii, sí wọn, kí wọ́n sọ fún wọn pé kí wọn má ṣe ohun ìríra tí n kò fẹ́.

5 Ṣugbọn wọn kò gbọ́ràn, wọn kò fetí sílẹ̀, wọn kò dáwọ́ ibi ṣíṣe dúró, wọn kò sì yé sun turari sí oriṣa mọ́.

6 Mo bá bínú gan-an sí àwọn ìlú Juda ati ìgboro Jerusalẹmu; mo sì sọ wọ́n di aṣálẹ̀ ati ahoro bí wọ́n ti wà lónìí.

7 “Èmi, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli wá ń bi yín léèrè pé, ‘Kí ló dé tí ẹ fi ń ṣe ara yín ní ibi tó báyìí? Ṣé ẹ fẹ́ kó gbogbo àwọn eniyan wọnyi kúrò ní ilẹ̀ Juda, ati àwọn ọkunrin ati àwọn obinrin, àtọmọ ọmú, àtọmọ ọwọ́, títí tí kò fi ní ku ẹnikẹ́ni ninu yín lẹ́yìn ni?

8 Kí ló dé tí ẹ fi ń fi iṣẹ́ ọwọ́ yín bí mi ninu, tí ẹ̀ ń sun turari sí àwọn oriṣa ní ilẹ̀ Ijipti, níbi tí ẹ̀ ń gbé? Ṣé ẹ fẹ́ kí n pa yín run, kí ẹ di ẹni ẹ̀sín láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni ẹ ṣe ń ṣe báyìí?

9 Ṣé ẹ ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín ṣe ní ilẹ̀ Juda ati ìgboro Jerusalẹmu, tí àwọn ọba Juda ati àwọn ayaba ṣe ati ẹ̀yin pẹlu àwọn iyawo yín?

10 Wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ títí di òní, tabi kí wọn bẹ̀rù, tabi kí wọ́n pa òfin ati ìlànà tí mo fún ẹ̀yin ati àwọn baba yín mọ́.’

11 “Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘Ẹ wò ó, n óo dójúlé yín, n óo sì pa gbogbo ọmọ Juda run.

12 N óo run gbogbo àwọn tí wọ́n ṣẹ́kù ní ilẹ̀ Juda tí wọ́n gbójú lé àtilọ máa gbé ilẹ̀ Ijipti, wọn kò ní ku ẹyọ kan ní ilẹ̀ Ijipti. Gbogbo wọn ni wọn óo parun láti orí àwọn mẹ̀kúnnù dé orí àwọn eniyan pataki pataki; ogun ati ìyàn ni yóo pa wọ́n. Wọn yóo di ẹni ìfibú, ẹni àríbẹ̀rù, ẹni ègún ati ẹni ẹ̀sín.

13 N óo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ Ijipti, n óo fi ogun, ìyàn, ati àjàkálẹ̀ àrùn pa wọ́n run bí mo ṣe fi pa Jerusalẹmu run.

14 Ẹnikẹ́ni kò ní yè ninu àwọn tí wọ́n ṣẹ́kù ní Juda, tí wọ́n lọ fi ilẹ̀ Ijipti ṣe ilé; wọn kò ní sá àsálà, wọn kò sì ní yè, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní pada sí ilẹ̀ Juda tí ọkàn wọn fẹ́ pada sí. Wọn kò ní pada, àfi àwọn bíi mélòó kan ni wọ́n óo sá àsálà.’ ”

15 Lẹ́yìn náà, gbogbo àwọn ọkunrin tí wọ́n mọ̀ pé àwọn iyawo wọn ń sun turari sí àwọn oriṣa ati àwọn obinrin tí wọ́n pọ̀ gbáà tí wọn wà nítòsí ibẹ̀, ati àwọn tí wọn ń gbé Patirosi ní ilẹ̀ Ijipti, wọ́n bá dá Jeremaya lóhùn,

16 wọ́n ní, “A kò ní fetí sì ọ̀rọ̀ tí ò ń bá wa sọ lórúkọ OLUWA.

17 Ṣugbọn a óo máa san gbogbo ẹ̀jẹ́ wa, a óo máa sun turari sí ọbabinrin ojú ọ̀run, oriṣa wa, a óo sì máa ta ohun mímu sílẹ̀, bí àwa ati àwọn baba ńlá wa, ati àwọn ọba wa ati àwọn olórí wa ti ṣe ní gbogbo ìlú Juda ati ní ìgboro Jerusalẹmu; nítorí pé nígbà náà à ń jẹ oúnjẹ ní àjẹyó, ó dára fún wa, ojú wa kò sì rí ibi.

18 Ṣugbọn láti ìgbà tí a ti dáwọ́ ati máa sun turari sí ọbabinrin ojú ọ̀run dúró, tí a kò sì máa ta ohun mímu sílẹ̀ mọ́, ni a kò ti ní nǹkankan mọ́, tí ogun ati ìyàn sì fẹ́ẹ̀ pa wá tán.”

19 Àwọn obinrin bá tún dáhùn pé, “Nígbà tí à ń sun turari sí ọbabinrin ojú ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ ohun mímu sí i, ṣé àwọn ọkọ wa ni kò mọ̀ pé à ń ṣe àkàrà dídùn, tí à ń ṣe bí ère rẹ̀ fún un ni, ati pé à ń ta ohun mímu sílẹ̀ fún un?”

20 Jeremaya sọ fún gbogbo àwọn eniyan tí wọ́n dá a lóhùn, lọkunrin ati lobinrin pé:

21 “Ṣebí OLUWA ranti turari tí ẹ̀yin ati àwọn baba yín, ati àwọn ọba yín, ati àwọn ìjòyè yín, ati gbogbo àwọn eniyan ilẹ̀ náà sun ninu àwọn ìlú Juda ati ní ìgboro Jerusalẹmu, ṣebí OLUWA ranti.

22 OLUWA kò lè farada ìwà burúkú tí ẹ̀ ń hù, ati àwọn nǹkan ìríra tí ẹ̀ ń ṣe, nítorí náà, ni ilẹ̀ yín ṣe di ahoro ati aṣálẹ̀, ati ilẹ̀ tí a fi ń gégùn-ún, tí kò ní olùgbé, títí di òní.

23 Ìdí tí èyí fi ṣẹlẹ̀ si yín ni pé ẹ sun turari, ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí OLUWA. Ẹ kò fetí sí ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ kò pa òfin, ati ìlànà rẹ̀ mọ́.”

24 Jeremaya dá gbogbo àwọn eniyan náà lóhùn, pataki jùlọ àwọn obinrin, ó ní, “Ẹ gbọ́ nǹkan tí OLUWA sọ, gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ẹ̀ ń gbé ilẹ̀ Ijipti,

25 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní, ‘Ẹ̀yin ati àwọn iyawo yín ti fi ẹnu ara yín sọ, ẹ sì ti fi ọwọ́ ara yín mú ohun tí ẹ wí ṣẹ pé, “Dájúdájú a ti jẹ́jẹ̀ẹ́ sí oriṣa ọbabinrin ojú ọ̀run láti sun turari sí i, ati láti rú ẹbọ ohun mímu sí i.” ’ Kò burú, ẹ mú ẹ̀jẹ́ yín ṣẹ!

26 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí, gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ẹ̀ ń gbé ilẹ̀ Ijipti: Ó ní, ‘Ẹ wò ó, mo ti fi orúkọ ńlá mi búra pé àwọn ará Juda tí wọ́n wà ní Ijipti kò ní fi orúkọ mi búra mọ́ pé “Bí OLUWA ti wà láàyè.”

27 Mo dójúlé yín láti ṣe yín ní ibi. Ibi ni n óo ṣe yín, n kò ní ṣe yín ní oore. Gbogbo àwọn ará Juda tí wọ́n wà ní Ijipti ni ogun ati ìyàn yóo pa láìku ẹnìkan.

28 Àwọn eniyan díẹ̀ ni wọn yóo sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ Ijipti lọ sí ilẹ̀ Juda. Gbogbo àwọn tí wọ́n bá ṣẹ́kù ní Juda, tí wọ́n lọ sí Ijipti yóo wá mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóo ṣẹ, bóyá tèmi ni, tabi tiwọn.

29 Èyí ni yóo jẹ́ àmì fun yín pé n óo jẹ yín níyà ní ilẹ̀ yìí, kí ẹ lè mọ̀ pé ọ̀rọ̀ ibi tí mo sọ si yín yóo ṣẹ mọ yín lára,

30 Èmi OLUWA ni mo sọ ọ́ pé n óo fi Farao Hofira ọba Ijipti lé ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́ ati àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekaya, ọba Juda lé ọwọ́ ọ̀tá rẹ̀, Nebukadinesari, ọba Babiloni, ẹni tí ó ń wá ọ̀nà láti pa á.’ ”

45

1 Ọ̀rọ̀ tí Jeremaya wolii sọ fún Baruku ọmọ Neraya nìyí, ní ọdún kẹrin tí Jehoiakimu, ọmọ Josaya, jọba ní Juda. Baruku ń kọ ohun tí Jeremaya ń sọ sílẹ̀ bí Jeremaya tí ń sọ̀rọ̀.

2 Ó ní: “OLUWA Ọlọrun Israẹli sọ fún ìwọ Baruku pé,

3 ò ń sọ pé, o gbé, nítorí pé OLUWA ti fi ìbànújẹ́ kún ìrora rẹ; àárẹ̀ mú ọ nítorí ìkérora rẹ, o kò sì ní ìsinmi.

4 “Èmi ń wó ohun tí mo kọ́ lulẹ̀, mo sì ń tu ohun tí mo gbìn, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ gbogbo ilẹ̀ náà rí.

5 Ìwọ ń wá nǹkan ńlá fún ara tìrẹ? Má wá nǹkan ńlá fún ara rẹ. Wò ó, n óo mú kí ibi bá gbogbo eniyan, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀; ṣugbọn n óo jẹ́ kí o máa sá àsálà ní gbogbo ibi tí o bá ń lọ.”

46

1 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA bá Jeremaya wolii sọ nípa àwọn orílẹ̀-èdè nìyí.

2 Ọ̀rọ̀ lórí Ijipti: Nípa àwọn ọmọ ogun Farao Neko, ọba Ijipti, tí wọ́n wà létí odò Yufurate ní Kakemiṣi, àwọn tí Nebukadinesari, ọba Babiloni, ṣẹgun ní ọdún kẹrin tí Jehoiakimu ọmọ Josaya jọba Juda.

3 “Ọ̀gágun Ijipti pàṣẹ fún àwọn ọmọ ogun rẹ̀ pé, ‘Ẹ tọ́jú asà ati apata, kí ẹ sì jáde sójú ogun!

4 Ẹ̀yin ẹlẹ́ṣin, ẹ di ẹṣin yín ní gàárì, kí ẹ sì gùn wọ́n. Ẹ dúró ní ipò yín, pẹlu àṣíborí lórí yín. Ẹ pọ́n àwọn ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ gbé ihamọra irin yín wọ̀!’ ”

5 Oluwa ní, “Kí ni mo rí yìí? Ẹ̀rù ń bà wọ́n, wọ́n sì ń pada sẹ́yìn. A ti lu àwọn ọmọ ogun wọn bolẹ̀, wọ́n sì ń sálọ pẹlu ìkánjú; wọn kò bojú wẹ̀yìn, ìpayà yí wọn ká!

6 Àwọn tí ẹsẹ̀ wọn yá nílẹ̀ kò lè sálọ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ ogun kò lè sá àsálà. Ìhà àríwá, lẹ́bàá odò Yufurate, ni wọ́n tí fẹsẹ̀ kọ, tí wọ́n sì ṣubú.

7 Ta ló ń ru bí odò Naili yìí, bí odò tí ó kún bo bèbè rẹ̀?

8 Ijipti ń ru bí odò Naili, bí odò tí ó kún bo bèbè rẹ̀. Ijipti wí pé, ‘N óo kún, n óo sì bo ayé mọ́lẹ̀, n óo pa àwọn ìlú ati àwọn tí wọn ń gbé inú wọn run.

9 Ó yá, ẹṣin, ẹ gbéra, kí kẹ̀kẹ́ ogun máa sáré kíkankíkan! Kí àwọn ọmọ ogun máa nìṣó, àwọn ọmọ ogun Etiopia ati Puti, tí wọ́n mọ asà á lò, àwọn ọmọ ogun Ludi, tí wọ́n mọ ọfà á ta dáradára.’ ”

10 Ọjọ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun ni ọjọ́ náà, ọjọ́ ẹ̀san, tí yóo gbẹ̀san ara rẹ̀ lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà rẹ̀ yóo pa àpatẹ́rùn, yóo sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn ní àmuyó. Nítorí OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní ń rúbọ, ní ìhà àríwá, lẹ́bàá odò Yufurate.

11 Gòkè lọ sí Gileadi, kí o lọ wá ìwọ̀ra, ẹ̀yin ará Ijipti, asán ni gbogbo òògùn tí ẹ lò, ẹ kò ní rí ìwòsàn.

12 Àwọn orílẹ̀ èdè ti gbọ́ nípa ìtìjú yín, igbe yín ti gba ayé kan; nítorí àwọn ọmọ ogun ń rọ́ lu ara wọn; gbogbo wọn sì ṣubú papọ̀.

13 Ohun tí OLUWA sọ fún wolii Jeremaya nípa Nebukadinesari, ọba Babiloni nígbà tí ó ń bọ̀ wá ṣẹgun ilẹ̀ Ijipti nìyí:

14 Ó ní, “Ẹ kéde ní Ijipti, ẹ polongo ní Migidoli, ní Memfisi ati ní Tapanhesi. Ẹ wí pé, ‘Ẹ gbáradì kí ẹ sì múra sílẹ̀, nítorí ogun yóo run yín yíká.

15 Kí ló dé tí àwọn akọni yín kò lè dúró? Wọn kò lè dúró nítorí pé OLUWA ni ó bì wọ́n ṣubú.’

16 Ogunlọ́gọ̀ yín ti fẹsẹ̀ kọ, wọ́n sì ṣubú, wọ́n wá ń wí fún ara wọn pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí á pada sọ́dọ̀ àwọn eniyan wa, ati sí ilẹ̀ tí wọn gbé bí wa, nítorí ogun àwọn aninilára.’

17 “Ẹ pa orúkọ Farao, ọba Ijipti dà, ẹ pè é ní, ‘Aláriwo tí máa ń fi anfaani rẹ̀ ṣòfò.’

18 Ọba, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun, fi ara rẹ̀ búra pé, bí òkè Tabori ti rí láàrin àwọn òkè, ati bí òkè Kamẹli létí òkun, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan tí yóo yọ si yín yóo rí.

19 Ẹ di ẹrù yín láti lọ sí ìgbèkùn, ẹ̀yin ará Ijipti! Nítorí pé Memfisi yóo di òkítì àlàpà, yóo di ahoro, kò sì ní sí ẹni tí yóo máa gbé ibẹ̀.

20 Ijipti dàbí ọmọ mààlúù tí ó lẹ́wà, ṣugbọn irù kan, tí ó ti ìhà àríwá fò wá, ti bà lé e.

21 Àwọn ọmọ ogun tí ó fi owó bẹ̀ lọ́wẹ̀, dàbí akọ mààlúù àbọ́pa láàrin rẹ̀; àwọn náà pẹ̀yìndà, wọ́n ti jọ sálọ, wọn kò lè dúró; nítorí ọjọ́ ìdààmú wọn ti dé bá wọn, ọjọ́ ìjìyà wọn ti pé.

22 Ó ń dún bí ejò tí ó ń sálọ; nítorí pé àwọn ọ̀tá rẹ̀ ń bọ̀ tagbára tagbára, wọ́n ń kó àáké bọ̀ wá bá a, bí àwọn tí wọn ń gé igi.

23 Wọn yóo gé igi inú igbó rẹ̀ lulẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbó náà dí, nítorí pé igi ibẹ̀ pọ̀ bí eṣú, tí wọn kò sì lóǹkà.

24 A óo dójú ti àwọn ará Ijipti, a óo fà wọ́n lé àwọn ará ìhà àríwá lọ́wọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

25 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ní: “N óo fi ìyà jẹ Amoni, oriṣa Tebesi, ati Farao, ati Ijipti pẹlu àwọn oriṣa rẹ̀, ati àwọn ọba rẹ̀. N óo fìyà jẹ Farao ati àwọn tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

26 N óo fà wọ́n lé àwọn tí wọn ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́; n óo fà wọ́n fún Nebukadinesari, ọba Babiloni, ati àwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀. Lẹ́yìn náà, àwọn eniyan yóo máa gbé Ijipti bíi ti àtijọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

27 “Ṣugbọn ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, iranṣẹ mi, ọmọ Israẹli, ẹ má fòyà; n óo gbà yín là láti ọ̀nà jíjìn, n óo kó arọmọdọmọ yín yọ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, ẹ óo pada máa gbé ní ìrọ̀rùn. Kò sì ní sí ẹni tí yóo dẹ́rù bà yín.

28 Ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, iranṣẹ mi, nítorí pé mo wà pẹlu yín. N óo run gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí mo le yín lọ, ṣugbọn n kò ní pa yín run. Bí ó bá tọ́ kí n jẹ yín níyà, n óo jẹ yín níyà, kìí ṣe pé n óo fi yín sílẹ̀ láìjẹ yín níyà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

47

1 OLUWA bá Jeremaya wolii sọ̀rọ̀ nípa Filistini kí Farao tó ṣẹgun Gasa,

2 Ó ní, “Wò ó, omi kan ń ru bọ̀ láti ìhà àríwá, yóo di àgbàrá tí ó lágbára; yóo ya bo ilẹ̀ yìí ati gbogbo ohun tí ó wà lórí rẹ̀, yóo ya bo ìlú yìí pẹlu, ati àwọn tí wọn ń gbé inú rẹ̀. Àwọn eniyan yóo kígbe: gbogbo àwọn ará ìlú yóo sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn.

3 Nígbà tí pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin bá ń dún, tí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ bá ń sáré, tí ẹsẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ ogun sì ń pariwo, Àwọn baba kò ní lè wo àwọn ọmọ wọn lẹ́yìn pé kí àwọn fà wọ́n, nítorí pé ọwọ́ wọn yóo rọ;

4 nítorí ọjọ́ tí ń bọ̀, tí yóo jẹ́ ọjọ́ ìparun gbogbo àwọn ará Filistia, ọjọ́ tí a óo run gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ tí ó kù fún Tire ati Sidoni. Nítorí pé OLUWA yóo pa àwọn ará Filistia run, àwọn tí wọ́n kù ní etí òkun ní Kafitori.

5 Ìbànújẹ́ ti dé bá Gasa, Aṣikeloni ti parun. Ẹ̀yin tí ẹ kù lára àwọn ọmọ Anakimu, ẹ óo ti fi ìbànújẹ́ ṣá ara yín lọ́gbẹ́ pẹ́ tó?

6 Ẹ̀yin ń bèèrè pé, ‘Ìwọ idà OLUWA, yóo ti pẹ́ tó kí o tó sinmi? Pada sinu àkọ̀ rẹ, máa sinmi kí o sì dúró jẹ́ẹ́.’

7 Ṣugbọn idà OLUWA ṣe lè dákẹ́ jẹ́ẹ́, nígbà tí Oluwa fún un ní iṣẹ́ láti ṣe? OLUWA ti pàṣẹ fún un láti kọlu Aṣikeloni, ati àwọn ìlú etí òkun.”

48

1 OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli sọ nípa Moabu pé, “Nebo gbé nítorí yóo di ahoro! Ojú yóo ti Kiriataimu nítorí ogun óo kó o; ìtìjú yóo bá ibi ààbò rẹ̀, wọn óo wó o lulẹ̀;

2 ògo Moabu ti dópin! Wọ́n ń pète ibi sí i ní Heṣiboni, wọ́n ní, ‘Ẹ jẹ́ kí á lọ pa á run, kí ó má jẹ́ orílẹ̀-èdè mọ́!’ Ẹ̀yin ará Madimeni pàápàá, kẹ́kẹ́ yóo pa mọ yín lẹ́nu; ogun yóo máa le yín kiri.

3 Gbọ́ igbe kan ní Horonaimu, igbe ìsọdahoro ati ìparun ńlá!

4 “Moabu ti parun; a gbọ́ igbe àwọn ọmọ rẹ̀.

5 Bí wọn tí ń gun òkè Luhiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń sọkún, nítorí pé nígbà tí wọn tí ń lọ níbi ẹsẹ̀ òkè Horonaimu, ni wọ́n tí ń gbọ́ igbe ìparun; pé,

6 ‘Ẹ sá! Ẹ sá àsálà fún ẹ̀mí yín! Ẹ sáré bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aṣálẹ̀!’

7 “Ọwọ́ yóo tẹ ìwọ náà, Moabu, nítorí pé o gbójú lé ibi ààbò ati ọrọ̀ rẹ. Oriṣa Kemoṣi yóo lọ sí ìgbèkùn, pẹlu àwọn babalóòṣà ati àwọn ìjòyè rẹ̀.

8 Apanirun yóo wọ gbogbo ìlú, ìlú kankan kò sì ní bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀; àwọn àfonífojì yóo pòórá, a óo sì pa àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀ run. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

9 Ẹ bá Moabu wá ìyẹ́, nítorí yóo fò bí ẹyẹ; àwọn ìlú rẹ̀ yóo di ahoro, kò ní ku ẹnikẹ́ni ninu wọn.”

10 (Ègún ń bẹ lórí ẹni tí ó bá ń fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ OLUWA; ègún sì ń bẹ lórí ẹni tí ó bá sì kọ̀, tí kò máa fi idà rẹ̀ pa eniyan.)

11 OLUWA ní, “Láti ìgbà èwe Moabu ni ó ti ń gbé pẹlu ìrọ̀rùn, kò tíì lọ sí ìgbèkùn rí. Nítorí náà ó silẹ̀ bí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ ọtí. A kò máa dà á kiri láti inú ìgò kan sí òmíràn. Adùn rẹ̀ ṣì wà lára rẹ̀, òórùn rẹ̀ kò sì tíì yipada.

12 “Nítorí náà, àkókò ń bọ̀, tí n óo jẹ́ kí wọn da Moabu nù, bí ẹni da ọtí nù. Àwọn tí wọn ń da ọtí nù ni n óo rán, tí wọn óo wá tẹ̀ ẹ́ bí ìgò ọtí wọn óo dà á nù patapata, wọn óo sì fọ́ ìgò rẹ̀.

13 Kemoṣi yóo di ohun ìtìjú fún Moabu, gẹ́gẹ́ bí Bẹtẹli, tí Israẹli gbójú lé, ṣe di ohun ìtìjú fún Israẹli.

14 Ẹ ṣe lè wí pé alágbára ni yín, ati pé ẹ jẹ́ akikanju lójú ogun?

15 Ẹni tí yóo pa ilẹ̀ Moabu ati àwọn ìlú rẹ̀ run ti dé, àwọn àṣàyàn ọmọkunrin rẹ̀ sì ti lọ sí ibi tí wọn ó ti pa wọ́n. Èmi ọba, tí orúkọ mi ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun, ni ó sọ bẹ́ẹ̀.

16 Ọjọ́ ìdààmú Moabu fẹ́rẹ̀ dé, ìpọ́njú rẹ̀ sì ń bọ̀ kánkán.

17 “Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ yí i ká, ẹ dárò rẹ̀, kí gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ orúkọ rẹ̀ sì wí pé, ‘Ọ̀pá àṣẹ tí ó lágbára ti kán, ọ̀pá àṣẹ tí ó lógo ti ṣẹ́.’

18 Sọ̀kalẹ̀ kúrò ninu ògo rẹ, kí o jókòó lórí ìyàngbẹ ilẹ̀, ìwọ tí ò ń gbé Diboni! Nítorí pé ẹni tí óo pa Moabu run ti dojú kọ ọ́, ó sì ti wó àwọn ibi ààbò rẹ̀.

19 Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o máa ṣọ́nà, ìwọ tí ò ń gbé Aroeri! Bèèrè lọ́wọ́ àwọn tí wọ́n sálọ; bi àwọn tí ń sá àsálà pé, ‘Kí ló ṣẹlẹ̀?’

20 Ìtìjú ti bá Moabu, nítorí pé ó ti wó lulẹ̀; ẹ kígbe, ẹ máa sọkún. Ẹ kéde rẹ̀ ní ipadò Anoni, pé, ‘Moabu ti parẹ́, ó ti di òkítì àlàpà.’

21 “Ìdájọ́ ti dé sórí àwọn ìlú tí ó wà ní ilẹ̀ tí ó tẹ́jú: Holoni, Jahisai, ati Mefaati;

22 Diboni, Nebo, ati Beti Dibilataimu,

23 Kiriataimu, Betigamuli, ati Betimeoni,

24 Kerioti, Bosira, ati gbogbo àwọn ìlú ilẹ̀ Moabu, ati àwọn tí wọ́n wà nítòsí, ati àwọn tí wọ́n wà lókèèrè.

25 Ipá Moabu ti pin, a sì ti ṣẹ́ ẹ lápá. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

26 OLUWA ní, “Ẹ rọ Moabu lọ́tí yó, nítorí pé ó gbéraga sí OLUWA; kí ó lè máa yíràá ninu èébì rẹ̀, a óo sì fi òun náà ṣẹ̀sín.

27 Moabu, ṣebí ò ń fi Israẹli ṣe yẹ̀yẹ́? Ṣé o bá a láàrin àwọn ọlọ́ṣà ni, tí ó fi jẹ́ pé nígbàkúùgbà tí o bá ń sọ̀rọ̀ rẹ̀, ń ṣe ni o máa ń mi orí rẹ?

28 “Ẹ fi ààrin ìlú sílẹ̀, kí ẹ lọ máa gbé inú àpáta, ẹ̀yin ará Moabu! Ẹ ṣe bí àdàbà, tí ó kọ́lé rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ ẹnu ihò àpáta.

29 A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu, ó ní ìgbéraga lọpọlọpọ, a ti gbọ́ nípa èrò gíga rẹ̀, ati ìgbéraga rẹ̀, nípa àfojúdi rẹ̀, ati nípa ìwà ìjọra-ẹni-lójú rẹ̀.

30 Mo mọ̀ pé aláfojúdi ni. Ó ń fọ́nnu lásán ni, kò lè ṣe nǹkankan tó yanjú.

31 Nítorí náà, ni mo ṣe ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, tí mò ń kígbe sókè nítorí Moabu tí mo sì ń ṣọ̀fọ̀ nítorí àwọn ará Kiri Heresi.

32 Ìwọ ọgbà àjàrà Sibima, ọ̀rọ̀ rẹ pa mí lẹ́kún, ju ti Jaseri lọ! Àwọn ẹ̀ka rẹ tàn dé òkun, wọ́n tàn títí dé Jaseri, apanirun sì ti kọlu àwọn èso ẹ̀ẹ̀rùn rẹ, ati èso àjàrà rẹ.

33 Wọ́n ti mú ayọ̀ ati ìdùnnú kúrò ní ilẹ̀ ọlọ́ràá Moabu; mo ti mú kí ọtí waini tán níbi tí wọ́n ti ń ṣe é, kò sí ẹni tí ó ń ṣe ọtí waini pẹlu ariwo ayọ̀ mọ́, ariwo tí wọn ń pa kì í ṣe ti ayọ̀.

34 “Heṣiboni ati Eleale kígbe sókè, igbe wọn sì dé Jahasi láti Soari, ó dé Horonaimu ati Egilati Ṣeliṣiya. Àwọn odò Nimrimu pàápàá ti gbẹ.

35 N óo pa àwọn tí ń rú ẹbọ níbi pẹpẹ ìrúbọ run, ati àwọn tí ń sun turari sí oriṣa ní ilẹ̀ Moabu.

36 “Nítorí náà ni mo ṣe ń dárò Moabu ati àwọn ará Kiri Heresi bí ẹni fi fèrè kọ orin arò nítorí pé gbogbo ọrọ̀ tí wọ́n kó jọ ti ṣègbé.

37 Gbogbo wọn ti fá irun orí ati irùngbọ̀n wọn; wọ́n ti fi abẹ ya gbogbo ọwọ́ wọn, wọ́n sì lọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ìbàdí.

38 Gbogbo eniyan ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn ní gbogbo orí ilé Moabu, ati àwọn ìta gbangba rẹ̀. Nítorí pé mo ti fọ́ Moabu, bíi ohun èlò tí ẹnikẹ́ni kò bìkítà fún. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

39 A ti fọ́ Moabu túútúú! Ẹ̀ ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn! Moabu pẹ̀yìndà pẹlu ìtìjú! Moabu wá di ẹni yẹ̀yẹ́ ati ẹni àríbẹ̀rù fún gbogbo àwọn tí wọ́n yí i ká.”

40 OLUWA ní, “Wò ó, ẹnìkan yóo fò wá bí ẹyẹ idì, yóo sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ lé Moabu lórí.

41 Ogun yóo kó àwọn ìlú Moabu, wọn óo sì gba àwọn ibi ààbò rẹ̀. Ní ọjọ́ náà, ọkàn àwọn ọmọ ogun Moabu yóo dàbí ọkàn obinrin tí ó ń rọbí,

42 Moabu yóo parun, kò ní jẹ́ orílẹ̀-èdè mọ́, nítorí pé ó ṣe ìgbéraga sí OLÚWA.

43 Ẹ̀yin ará Moabu, ìpayà, ọ̀gbun ati tàkúté ń bẹ níwájú yín!

44 Ẹni tí ó ń sálọ nítorí ìpayà, yóo jìn sinu ọ̀gbun, ẹni tí ó bá sì jáde ninu ọ̀gbun yóo kó sinu tàkúté. N óo mú kí àwọn nǹkan wọnyi dé bá Moabu nígbà tí àkókò ìjìyà rẹ̀ bá tó. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

45 Àwọn tí wọn ń sá fún ogun dúró ní ibi ààbò Heṣiboni, wọn kò lágbára mọ́, nítorí iná ṣẹ́ jáde láti Heṣiboni ahọ́n iná sì yọ láàrin ilé Sihoni ọba; iná ti jó Moabu tíí ṣe adé àwọn ọmọ onídàrúdàpọ̀ ní àjórun,

46 Ẹ̀yin ará Moabu, ẹ gbé! Ó ti parí fun yín, ẹ̀yin ọmọ Kemoṣi, nítorí a ti kó àwọn ọmọkunrin yín lẹ́rú, a ti kó àwọn ọmọbinrin yín lọ sí ìgbèkùn.

47 “Sibẹsibẹ n óo dá ire Moabu pada lẹ́yìn ọ̀la, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóo rí fún Moabu.”

49

1 Ohun tí OLUWA sọ nípa àwọn ará Amoni nìyí: Ó ní, “Ṣé Israẹli kò lọ́mọ ni? Tabi kò ní àrólé? Kí ló dé tí àwọn tí ń bọ Milikomu ṣe gba ilẹ̀ ẹ̀yà Gadi, tí wọ́n sì fi àwọn ìlú Gadi ṣe ibùjókòó?

2 Nítorí náà, wò ó, àkókò ń bọ̀ tí n óo jẹ́ kí ariwo ogun sọ, ní Raba ìlú àwọn ọmọ Amoni; Raba yóo di òkítì àlàpà, a óo sì dáná sun àwọn ìgbèríko rẹ̀; Israẹli yóo wá pada fi ogun kó àwọn tí wọ́n kó o lẹ́rú.

3 Sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ìwọ Heṣiboni, nítorí pé ìlú Ai ti parun! Ẹ sọkún, ẹ̀yin ọmọbinrin Raba! Ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ máa sọkún, kí ẹ sì máa sá sókè sódò láàrin ọgbà! Nítorí pé oriṣa Moleki yóo lọ sí ìgbèkùn, pẹlu àwọn babalóòṣà rẹ̀ ati àwọn ìjòyè ní ibi ìsìn rẹ̀.

4 Kí ló dé tí ò ń fọ́nnu nípa agbára rẹ, ipá rẹ ti pin, ìwọ olóríkunkun ọmọbinrin ìwọ tí o gbójú lé ọrọ̀ rẹ, tí ò ń wí pé, ‘Ta ló lè dojú kọ mí?’

5 Wò ó! N óo kó ìpayà bá ọ, láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí wọ́n yí ọ ká; èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Gbogbo yín ni yóo fọ́nká, tí olukuluku yóo sì yà sí ọ̀nà tirẹ̀, kò sì ní sí ẹni tí yóo kó àwọn tí ń sá fún ogun jọ.

6 “Ṣugbọn lẹ́yìn náà, n óo dá ire àwọn ará Amoni pada. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

7 Ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa Edomu nìyí: Ó ní, “Ṣé kò sí ọgbọ́n ní Temani mọ́ ni? Àbí àwọn amòye kò ní ìmọ̀ràn lẹ́nu mọ́? Ṣé ọgbọ́n ti rá mọ́ wọn ninu ni?

8 Ẹ̀yin ará Dedani, ẹ pada kíá, ẹ máa sálọ. Ẹ wọ inú ihò lọ, kí ẹ lọ máa gbébẹ̀! Nítorí pé ní ìgbà tí mo bá jẹ ìran Esau níyà, n óo mú kí ibi dé bá wọn.

9 Bí àwọn tí ń kórè èso àjàrà bá bẹ̀rẹ̀ sí kórè, ṣebí wọn a máa fi èso díẹ̀ díẹ̀ sílẹ̀? Bí àwọn olè bá wọlé lóru, ṣebí ìba ohun tí ó bá wù wọ́n ni wọn yóo kó?

10 Ṣugbọn mo ti tú àwọn ọmọ Esau sí ìhòòhò, Mo ti sọ ibi tí wọn ń sápamọ́ sí di gbangba, wọn kò sì rí ibi sápamọ́ sí mọ́. Àwọn ọmọ wọn ti parun, pẹlu àwọn arakunrin wọn ati àwọn aládùúgbò wọn; àwọn pàápàá sì ti di àwátì.

11 Fi àwọn ọmọ rẹ, aláìníbaba sílẹ̀, n óo pa wọ́n mọ́ láàyè, sì jẹ́ kí àwọn opó rẹ gbẹ́kẹ̀lé mi.

12 “Bí àwọn tí kò yẹ kí wọ́n jìyà bá jìyà, ṣé ìwọ wá lè lọ láìjìyà? O kò ní lọ láìjìyà, dájúdájú ìyà óo jẹ ọ́.

13 Nítorí pé mo ti fi ara mi búra, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀, pé Bosira yóo di àríbẹ̀rù ati ohun ẹ̀gàn, ahoro ati ohun àmúgégùn-ún; àwọn ìlú rẹ̀ yóo sì di ahoro títí lae.”

14 Mo ti gbọ́ ìròyìn láti ọ̀dọ̀ OLUWA, wọ́n ti rán ikọ̀ kan sí àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n ní kí wọn kéde pé, “OLUWA ní, ‘Ẹ kó ara yín jọ, kí ẹ kọlu Edomu, ẹ dìde, kí ẹ gbógun tì í!

15 Nítorí pé n óo sọ ọ́ di kékeré láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, o óo sì di yẹpẹrẹ, láàrin àwọn ọmọ eniyan.

16 Ẹ̀rù tí ó wà lára rẹ, ati ìgbéraga ọkàn rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ò ń gbé pàlàpálá àpáta, tí o fi góńgó orí òkè ṣe ibùgbé. Bí o tilẹ̀ kọ́ ìtẹ́ rẹ sí ibi gíga, bíi ti ẹyẹ idì, n óo fà ọ́ lulẹ̀ láti ibẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.’ ”

17 OLUWA ní, “Edomu yóo sì di ibi àríbẹ̀rù, ẹ̀rù yóo máa ba gbogbo àwọn tí wọ́n bá gba ibẹ̀ kọjá, wọn yóo máa pòṣé nítorí ibi tí ó dé bá a.

18 Yóo rí fún un bí ó ti rí fún Sodomu ati Gomora ati àwọn ìlú agbègbè wọn tí ó parun. Ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò ní dé sibẹ. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

19 Wò ó, bí kinniun tií yọ ní aginjù odò Jọdani láti kọlu agbo aguntan, bẹ́ẹ̀ ni n óo yọ sí Edomu n óo sì mú kí ó sá kúrò lórí ilẹ̀ rẹ̀ lójijì. N óo sì yan ẹnikẹ́ni tí ó bá wù mí láti máa ṣe àkóso ibẹ̀; nítorí ta ló dàbí mi? Ta ló lè yẹ̀ mí lọ́wọ́ wò? Olùṣọ́-aguntan wo ló lè dúró dè mí?

20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ète tí OLUWA pa lórí Edomu, ati èrò rẹ̀ lórí àwọn tí wọn ń gbé Temani. A óo kó agbo ẹran wọn lọ tọmọtọmọ, ibùjẹ àwọn ẹran wọn yóo parun nítorí tiwọn.

21 Ariwo wíwó odi Edomu wọn yóo mi ilẹ̀ tìtì, a óo sì gbọ́ ìró rẹ̀ títí dé etí òkun pupa.

22 Wò ó! Ẹnìkan yóo fò bí ẹyẹ idì, yóo na ìyẹ́ rẹ̀ sórí Bosira, ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ọmọ ogun Edomu yóo dàbí ọkàn obinrin tí ń rọbí.”

23 Ohun tí OLUWA sọ nípa Damasku nìyí, Ó ní, “Ìdààmú dé bá Hamati ati Aripadi, nítorí pé wọ́n gbọ́ ìròyìn burúkú: Jìnnìjìnnì dà bò wọ́n, ọkàn wọn sì dàrú, bí omi òkun tí kò lè dákẹ́ jẹ́ẹ́.

24 Àárẹ̀ mú Damasku, ó pẹ̀yìndà pé kí ó máa sálọ, ṣugbọn ìpayà mú un, ìrora ati ìbànújẹ́ sì dé bá a, bí obinrin tí ń rọbí.

25 Ẹ wò ó bí ìlú olókìkí tí ó kún fún ayọ̀, ṣe di ibi ìkọ̀sílẹ̀!

26 Àwọn ọdọmọkunrin Damasku yóo ṣubú ní gbàgede rẹ̀ ní ọjọ́ náà, gbogbo àwọn ọmọ ogun ibẹ̀ yóo sì parun ni; Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

27 N óo dáná sun odi Damasku, yóo sì jó ibi ààbò Benhadadi.”

28 OLUWA sọ nípa Kedari ati àwọn ìjọba Hasori tí Nebukadinesari ọba Babiloni ṣẹgun pé, “Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti Kedari! Ẹ pa àwọn ará ìlà oòrùn run!

29 Ogun yóo kó àgọ́ wọn ati àwọn ẹran ọ̀sìn wọn lọ, ati àwọn aṣọ àgọ́, ati ohun ìní wọn; Ọ̀tá yóo kó ràkúnmí wọn lọ, àwọn eniyan yóo máa kígbe sí wọn pé, ‘Ìpayà wà ní gbogbo àyíká.’

30 “Ẹ̀yin ará Hasori, ẹ sá, ẹ lọ jìnnà réré, kí ẹ sì máa gbé inú ọ̀gbun. Nítorí pé Nebukadinesari, ọba Babiloni ń pète ibi si yín, ó ti pinnu ibi si yín.

31 Ó ní, ‘Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti orílẹ̀-èdè tí ó wà ní alaafia, ati láìléwu, ìlú tí ó dá dúró tí kò sì ní ìlẹ̀kùn tabi ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn fún ààbò.’

32 “Àwọn ràkúnmí ati agbo ẹran wọn yóo di ìkógun. N óo fọ́n àwọn tí wọn ń gé ẹsẹ̀ irun wọn ká sí igun mẹrẹẹrin ayé, n óo sì mú kí ibi bá wọn láti gbogbo àyíká wọn.

33 Hasori yóo di ibùgbé ajáko, yóo di ahoro títí laelae. Ẹnìkan kò ní gbé ibẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò ní dé sibẹ mọ́.”

34 OLUWA àwọn ọmọ ogun bá Jeremaya wolii sọ nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekaya, ọba Juda.

35 Ó ní, “Wò ó! N óo pa àwọn tafàtafà Elamu, tí wọn jẹ́ orísun agbára wọn,

36 n óo mú kí ẹ̀fúùfù mẹrin láti igun mẹrẹẹrin ojú ọ̀run kọlu Elamu; n óo sì fọ́n wọn ká sinu ẹ̀fúùfù náà, kò sì ní sí orílẹ̀-èdè kan tí àwọn ará Elamu kò ní fọ́n ká dé.

37 N óo dẹ́rùbà wọ́n; níwájú àwọn ọ̀tá wọn, ati níwájú àwọn tí ń wá ọ̀nà ati pa wọ́n. N óo bínú sí wọn gan-an, n óo sì mú kí ibi dé bá wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo rán ogun tẹ̀lé wọn, títí n óo fi pa wọ́n tán.

38 N óo tẹ́ ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, n óo sì pa ọba ati àwọn ìjòyè wọn.

39 Ṣugbọn nígbẹ̀yìn, n óo dá ire Elamu pada. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

50

1 OLUWA bá wolii Jeremaya sọ̀rọ̀ nípa Babiloni ní ilẹ̀ àwọn ará Kalidea pé:

2 “Kéde láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, ta àsíá, kí o sì kéde. Má fi ohunkohun pamọ́; sọ pé, ‘Ogun tí kó Babiloni, ojú ti oriṣa Bẹli, oriṣa Merodaki wà ninu ìdààmú. Ojú ti àwọn ère rẹ̀, ìdààmú sì bá wọn.’

3 “Nítorí pé orílẹ̀-èdè kan láti ìhà àríwá ti gbógun tì í, yóo sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ahoro, kò sì ní sí ẹni tí yóo gbé inú rẹ̀ mọ́, ati eniyan ati ẹranko, wọn óo sá kúrò níbẹ̀.

4 “Nígbà tí àkókò bá tó, àwọn ọmọ Israẹli ati àwọn ọmọ Juda, yóo jọ wá pẹlu ẹkún, wọn yóo máa wá OLUWA Ọlọrun wọn.

5 Wọn yóo bèèrè ọ̀nà Sioni, wọn yóo kọjú sibẹ, wọn yóo sì wí pé: ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á darapọ̀ mọ́ OLUWA, kí á sì bá a dá majẹmu ayérayé, tí a kò ní gbàgbé mọ́ títí ayé.’

6 “Àwọn eniyan mi dàbí aguntan tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́ wọn ti ṣì wọ́n lọ́nà. Wọ́n ń lọ síhìn-ín, sọ́hùn-ún lórí òkè, wọ́n ń ti orí òkè kéékèèké bọ́ sí orí òkè ńláńlá; wọ́n ti gbàgbé ọ̀nà agbo wọn.

7 Gbogbo àwọn tí wọn rí wọn ń pa wọ́n jẹ, àwọn ọ̀tá wọn sì ń wí pé, ‘A kò ní ẹ̀bi kankan, nítorí pé wọ́n ti ṣẹ OLÚWA, tí ó jẹ́ ibùgbé òdodo wọn, ati ìrètí àwọn baba wọn.’

8 “Ẹ sá kúrò láàrin Babiloni, ẹ jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kalidea, bí òbúkọ tí ó ṣáájú agbo ẹran.

9 Nítorí n óo rú ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè sókè, láti ìhà àríwá, n óo sì kó wọn wá, wọn óo wá dóti Babiloni, wọn yóo gbógun tì í. Ibẹ̀ ni ọwọ́ wọn yóo ti tẹ̀ ẹ́, tí wọn óo sì fogun kó o. Ọfà wọn dàbí akọni ọmọ ogun, tí kì í pada sílé lọ́wọ́ òfo.

10 Ohun ìní àwọn ará Kalidea yóo di ìkógun; gbogbo àwọn tí wọn yóo kó wọn lẹ́rù ni yóo kó ẹrù ní àkótẹ́rùn, Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11 OLUWA ní, “Ẹ̀yin ará Babiloni, tí ẹ kó àwọn eniyan mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé inú yín dùn ẹ sì ń yọ̀, tí ẹ sì ń ṣe ojúkòkòrò, bí akọ mààlúù tí ń jẹko ninu pápá, tí ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin:

12 Ojú yóo ti olú-ìlú yín lọpọlọpọ, a óo dójú ti ilẹ̀ ìbí yín. Wò ó! Yóo di èrò ẹ̀yìn láàrin àwọn orílẹ̀-èdè, yóo di aṣálẹ̀ tí ó gbẹ.

13 Nítorí ibinu gbígbóná OLUWA, ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀ mọ́; yóo di ahoro patapata; ẹnu yóo ya gbogbo ẹni tí ó bá gba Babiloni kọjá, wọn yóo sì máa pòṣé nítorí ìyà tí a fi jẹ ẹ́.

14 “Ẹ gbógun ti Babiloni yíká, gbogbo ẹ̀yin tafàtafà. Ẹ máa ta á lọ́fà, ẹ má ṣẹ́ ọfà kankan kù, nítorí pé ó ti ṣẹ OLUWA.

15 Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ yí i ká, ẹ hó bò ó, ó ti jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn ibi ààbò rẹ̀ ti wó, àwọn odi rẹ̀ sì ti wó lulẹ̀. Nítorí ẹ̀san OLUWA ni, ẹ gbẹ̀san lára rẹ̀; ẹ ṣe sí i bí òun náà ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.

16 Ẹ pa àwọn afunrugbin run ní Babiloni, ati àwọn tí ń lo dòjé ní ìgbà ìkórè. Olukuluku yóo pada sọ́dọ̀ àwọn eniyan rẹ̀, yóo sì sá pada sí ilẹ̀ rẹ̀, nítorí idà àwọn aninilára.”

17 OLUWA ní, “Israẹli dàbí aguntan tí àwọn kinniun ń lé kiri. Ọba Asiria ni ó kọ́kọ́ fi ṣe ẹran ìjẹ, ọba Babiloni sì ń wó àwọn egungun rẹ̀ tí ó kù.

18 Nítorí náà èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli, ni mo sọ pé n óo jẹ ọba Babiloni ati ilẹ̀ rẹ̀ níyà, bí mo ṣe jẹ ọba Asiria níyà.

19 N óo mú Israẹli pada sí ibùjẹ rẹ̀, yóo máa jẹ oúnjẹ tí ó bá hù lórí òkè Kamẹli ati ní agbègbè Baṣani, yóo sì tẹ́ ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn lórí òkè Efuraimu ati òkè Gileadi.

20 OLUWA ní, Nígbà tí ó bá yá, tí àkókò bá tó, a óo wá ẹ̀ṣẹ̀ tì ní Israẹli ati Juda; nítorí pé n óo dáríjì àwọn tí mo bá ṣẹ́kù.”

21 OLUWA ní, “Ẹ gbógun ti ilẹ̀ Merataimu, ati àwọn ará Pekodi. Ẹ pa wọ́n, kí ẹ sì run wọ́n patapata. Gbogbo nǹkan tí mo pàṣẹ fun yín ni kí ẹ ṣe. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

22 A gbọ́ ariwo ogun ati ìparun ńlá, ní ilẹ̀ náà.

23 Ẹ wo bí a ti gé òòlù tó ti ń lu gbogbo ayé lulẹ̀, tí a sì fọ́ ọ! Ẹ wo bí Babiloni ti di ohun àríbẹ̀rù, láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.

24 Mo dẹ tàkúté sílẹ̀ fun yín, ẹ̀yin ará Babiloni: Tàkúté náà mu yín, ẹ kò sì mọ̀. Wọ́n ri yín, ọwọ́ sì tẹ̀ yín, nítorí pé ẹ yájú sí èmi OLUWA.

25 Mo ti ṣí ìlẹ̀kùn ilé ìṣúra àwọn nǹkan ìjà yín, mo sì kó àwọn ohun ìjà ibinu yín jáde, nítorí èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní iṣẹ́ kan láti ṣe ní ilẹ̀ àwọn ará Kalidea.

26 Ẹ gbógun tì í ní gbogbo ọ̀nà, ẹ ṣí àká rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkítì ọkà, kí ẹ sì pa á run patapata, ẹ má dá ohunkohun sí ninu rẹ̀.

27 Ẹ pa gbogbo akọ mààlúù rẹ̀, ẹ fà wọ́n lọ sí ibi tí wọ́n ti ń pa ẹran. Àwọn ará Babiloni gbé, nítorí ọjọ́ wọn ti pé, àní ọjọ́ ìjìyà wọn.”

28 (Ẹ gbọ́ ariwo bí àwọn eniyan tí ń sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ Babiloni, wá sí Sioni, láti wá ròyìn ìgbẹ̀san Ọlọrun wa, ẹ̀san tẹmpili rẹ̀ tí wọ́n wó lulẹ̀.)

29 “Ẹ pe àwọn tafàtafà jọ, kí wọn dojú kọ Babiloni; kí gbogbo àwọn tí wọn ń tafà pàgọ́ yí i ká, kí wọn má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni sá àsálà. Ẹ san án fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ẹ ṣe sí i bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn; nítorí pé ó ṣe àfojúdi sí OLUWA, Ẹni Mímọ́ Israẹli.

30 Nítorí náà àwọn ọdọmọkunrin rẹ̀, yóo kú ní gbàgede rẹ̀. Gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ ní a óo parun ní ọjọ́ náà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

31 “Wò ó! Mo dojú kọ ọ́, ìwọ onigbeeraga yìí, nítorí pé ọjọ́ ti pé tí n óo jẹ ọ́ níyà. Èmi OLUWA, Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

32 Agbéraga, o óo fẹsẹ̀ kọ, o óo sì ṣubú, kò ní sí ẹni tí yóo gbé ọ dìde. N óo dá iná kan ninu àwọn ìlú rẹ, iná náà yóo sì jó gbogbo àyíká rẹ.”

33 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “À ń ni àwọn ọmọ Israẹli lára, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ọmọ Juda; gbogbo àwọn tí wọ́n kó wọn ní ìgbèkùn ni wọ́n wo ọwọ́ mọ́ wọn, wọn kò jẹ́ kí wọn lọ.

34 Ṣugbọn alágbára ni Olùràpadà wọn, OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀. Dájúdájú, yóo jà fún wọn, kí ó lè fún ayé ní ìsinmi, ṣugbọn kí ìdààmú lè bá àwọn ará Babiloni.”

35 OLUWA ní, “Idà ni yóo pa àwọn ará Kalidea, idà ni yóo pa àwọn ará Babiloni, ati àwọn ìjòyè wọn, ati àwọn amòye wọn!

36 Idà ni yóo pa àwọn awoṣẹ́ wọn, kí wọ́n lè di òpè! Idà ni yóo pa àwọn ọmọ ogun wọn, kí wọ́n lè parẹ́!

37 Idà ni yóo pa àwọn ẹṣin wọn, ati àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn, idà ni yóo pa gbogbo àwọn àjèjì ọmọ ogun tí wọ́n wà láàrin wọn, Kí wọ́n lè di obinrin! Idà ni yóo fọ́ àwọn ilé ìṣúra wọn, kí wọ́n lè di ìkógun!

38 Ọ̀dá yóo dá ní ilẹ̀ wọn, kí àwọn odò wọn lè gbẹ! Nítorí pé ilẹ̀ tí ó kún fún ère ni, wọ́n sì kúndùn ìbọ̀rìṣà.

39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ìgbẹ́ ati ìkookò ni yóo máa gbé inú Babiloni, ẹyẹ ògòǹgò yóo máa gbé inú rẹ̀. Kò ní sí eniyan níbẹ̀, ẹnikẹ́ni kò ní gbé inú rẹ̀ mọ́ títí lae.

40 Yóo dàbí ìgbà tí Ọlọrun pa Sodomu ati Gomora run, pẹlu àwọn ìlú tí ó yí wọn ká; nítorí náà ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni eniyan kò ní máa dé sibẹ.

41 “Wò ó! Àwọn kan ń bọ̀ láti ìhà àríwá, orílẹ̀-èdè ńlá, ati ọpọlọpọ ọba, wọ́n ń gbára wọn jọ láti máa bọ̀ láti òkèèrè.

42 Wọ́n kó ọrun ati ọ̀kọ̀ lọ́wọ́, ìkà ni wọ́n, wọn kò ní ojú àánú. Ìró wọn dàbí ìró rírú omi òkun; wọ́n gun ẹṣin, wọ́n tò bí àwọn ọmọ ogun. Wọ́n ń bọ̀ wá dojú kọ ọ́, ìwọ Babiloni!

43 Nígbà tí ọba Babiloni gbọ́ ìró wọn, ọwọ́ rẹ̀ rọ, ìrora sì mú un bíi ti obinrin tí ń rọbí.

44 “Wò ó! Bí kinniun tíí yọ ní aginjù odò Jọdani tíí kọlu agbo aguntan, bẹ́ẹ̀ ni n óo yọ sí àwọn ará Babiloni, n óo mú kí wọn sá kúrò lórí ilẹ̀ wọn lójijì; n óo sì yan ẹnikẹ́ni tí ó bá wù mí láti máa ṣe àkóso ibẹ̀. Nítorí ta ló dàbí mi? Ta ló lè yẹ̀ mí lọ́wọ́ wò? Olùṣọ́-aguntan wo ló lè dúró dè mí?

45 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ète tí èmi OLUWA pa lórí Babiloni, ati èrò mi lórí àwọn ará Kalidea: A óo kó agbo ẹran wọn lọ tọmọtọmọ; ibùjẹ ẹran wọn yóo sì parun nítorí tiwọn.

46 Ariwo wíwó odi Babiloni yóo mi ilẹ̀ tìtì, a óo sì gbọ́ ìró rẹ̀ káàkiri àwọn orílẹ̀-èdè.”

51

1 OLUWA ní, “Wò ó! N óo gbé ẹ̀mí apanirun kan dìde sí Babiloni, ati sí àwọn ará Kalidea;

2 n óo rán ìjì líle kan sí Babiloni, ìjì náà yóo fẹ́ ẹ dànù bí ìyàngbò ọkà yóo sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ahoro, nígbà tí wọ́n bá gbógun tì í yípo, ní ọjọ́ ìpọ́njú.

3 Kí tafàtafà má kẹ́ ọrun rẹ̀, kí ó má sì gbé ẹ̀wù irin rẹ̀ wọ̀. Má ṣe dá àwọn ọdọmọkunrin rẹ̀ sí, pa gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ run patapata.

4 Kí wọ́n ṣubú, kí wọ́n sì kú ní ilẹ̀ Kalidea, kí wọ́n gún wọn ní àgúnyọ láàrin ìgboro.

5 Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ati Juda kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀; ṣugbọn ilẹ̀ Kalidea kún fún ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n dá sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.

6 Ẹ sá kúrò láàrin Babiloni, kí olukuluku sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀! Ẹ má parun nítorí ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ Babiloni; nítorí àkókò ẹ̀san OLUWA nìyí, yóo sì san ẹ̀san fún Babiloni.

7 Ife wúrà ni Babiloni jẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, ó ń pa gbogbo ayé bí ọtí; àwọn orílẹ̀-èdè mu ninu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n.

8 Babiloni ṣubú lójijì, ó sì fọ́; ẹ sun ẹkún arò nítorí rẹ̀! Ẹ fi ìwọ̀ra pa á lára nítorí ìrora rẹ̀, bóyá ara rẹ̀ yóo yá.

9 À bá wo Babiloni sàn, ṣugbọn a kò rí i wòsàn. Ẹ pa á tì, ẹ jẹ́ kí á lọ, kí olukuluku máa lọ sí ilẹ̀ rẹ̀; nítorí ẹjọ́ tí a dá a ti dé òkè ọ̀run, a sì ti gbé e sókè dé ojú ọ̀run.”

10 OLUWA ti dá wa láre; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á lọ ròyìn iṣẹ́ OLUWA Ọlọrun wa ní Sioni.

11 Ẹ pọ́n ọfà yín! Ẹ gbé asà yín! Nítorí OLUWA ti ru ẹ̀mí àwọn ọba Media sókè, nítorí pé ó ti pinnu láti pa Babiloni run. Ẹ̀san OLUWA ni, ẹ̀san nítorí tẹmpili rẹ̀ tí wọ́n wó.

12 Ẹ gbé àsíá kan sókè, ẹ gbé e ti odi Babiloni; ẹ ṣe ìsénà tí ó lágbára. Ẹ fi àwọn aṣọ́nà sí ipò wọn; ẹ dira fún àwọn kan, kí wọn sápamọ́, nítorí OLUWA ti pinnu, ó sì ti ṣe ohun tí ó sọ nípa àwọn ará Babiloni.

13 Ìwọ Babiloni, tí odò yí ká, tí ìṣúra rẹ pọ̀ lọpọlọpọ, òpin ti dé bá ọ, okùn tí ó so ayé rẹ rọ̀ ti já.

14 OLUWA àwọn ọmọ ogun ti fi ara rẹ̀ búra, pé òun yóo mú kí àwọn eniyan kún inú rẹ bí eṣú, wọn yóo sì kígbe ìṣẹ́gun lé ọ lórí.

15 OLUWA ni ó fi agbára rẹ̀ dá ilé ayé, tí ó fi ìdí ayé múlẹ̀ pẹlu ìmọ̀ rẹ̀, ó sì fi òye rẹ̀ ta àwọn ọ̀run bí aṣọ.

16 Nígbà tí ó bá sọ̀rọ̀, ojú ọ̀run yóo kún fún alagbalúgbú omi, ó sì ń mú ìkùukùu gòkè láti òpin ilẹ̀ ayé. Ó dá mànàmáná fún òjò, ó sì mú ìjì jáde láti inú ilé ìṣúra rẹ̀.

17 Òmùgọ̀ ni gbogbo eniyan, wọn kò sì ní ìmọ̀, gbogbo alágbẹ̀dẹ wúrà sì gba ìtìjú lórí oriṣa tí wọn dà; nítorí pé irọ́ ni ère tí wọ́n rọ, wọn kò ní èémí.

18 Asán ni wọ́n, wọ́n ń ṣini lọ́nà, píparun ni wọn yóo parun, ní ọjọ́ ìjìyà wọn.

19 Ọlọrun ti Jakọbu kò dàbí àwọn wọnyi, nítorí pé òun ní ẹlẹ́dàá ohun gbogbo; ẹ̀yà Israẹli ni eniyan tirẹ̀, OLUWA àwọn ọmọ ogun sì ni orúkọ rẹ̀. OLUWA sọ fún Babiloni pé,

20 “Ìwọ ni òòlù ati ohun ìjà mi: ìwọ ni mo fi wó àwọn orílẹ̀-èdè wómúwómú, ìwọ ni mo sì fi pa àwọn ìjọba run.

21 Ìwọ ni mo fi lu ẹṣin ati ẹni tí ń gùn ún pa; ìwọ ni mo fi wó kẹ̀kẹ́ ogun ati àwọn tí ń bẹ ninu wọn.

22 Ìwọ ni mo fi lu tọkunrin tobinrin pa, ìwọ ni mo fi lu tọmọde, tàgbà pa, ìwọ ni mo sì fi run àwọn ọdọmọkunrin ati ọdọmọbinrin.

23 Ìwọ ni mo fi pa olùṣọ́-aguntan ati agbo ẹran rẹ̀ rẹ́, ìwọ ni mo fi run àgbẹ̀ ati àwọn alágbàro rẹ̀, ìwọ ni mo fi ṣẹ́ apá àwọn gomina ati ti àwọn olórí ogun.”

24 OLUWA ní, “Níṣojú yín ni n óo fi san ẹ̀san fún Babiloni, ati gbogbo àwọn tí wọn ń gbé Kalidea, fún gbogbo ibi tí wọ́n ṣe sí Sioni; èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

25 Wò ó! Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè ìparun, tí ò ń pa gbogbo ayé run. N óo gbá ọ mú, n óo tì ọ́ lulẹ̀ láti orí àpáta, n óo sì sọ ọ́ di òkè tí ó jóná.

26 Wọn kò ní rí òkúta kan mú jáde ninu rẹ, tí eniyan lè fi ṣe òkúta igun ilé; tabi tí wọn lè fi ṣe ìpìlẹ̀ ilé, ń ṣe ni o óo wó lulẹ̀ títí ayé. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

27 “Ẹ ta àsíá sórí ilẹ̀ ayé, ẹ fun fèrè ogun láàrin àwọn orílẹ̀-èdè; kí àwọn orílẹ̀-èdè múra láti gbógun tì í, ẹ sì pe àwọn ìjọba jọ láti dojú kọ ọ́; àwọn ìjọba orílẹ̀-èdè bíi Ararati, Minni, ati Aṣikenasi. Ẹ yan balogun tí yóo gbógun tì í; ẹ kó ẹṣin wá, kí wọn pọ̀ bí eṣú.

28 Kí àwọn orílẹ̀-èdè múra láti gbógun tì í, kí àwọn ọba ilẹ̀ Media múra, pẹlu àwọn gomina wọn, ati àwọn ẹmẹ̀wà wọn, ati gbogbo ilẹ̀ tí ó wà lábẹ́ wọn.

29 Jìnnìjìnnì bo gbogbo ilẹ̀ náà, wọ́n wà ninu ìrora, nítorí pé OLUWA kò yí ìpinnu rẹ̀ lórí Babiloni pada, láti sọ ilẹ̀ náà di ahoro, láìsí ẹnìkan kan ninu rẹ̀ mọ́.

30 Àwọn ọmọ ogun Babiloni ti ṣíwọ́ ogun jíjà, wọ́n wà ní ibi ààbò wọn; àárẹ̀ ti mú wọn, wọ́n sì ti di obinrin. Àwọn ilé inú rẹ̀ ti ń jóná, àwọn ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ sì ti ṣẹ́.

31 Àwọn tí ń sáré ń pàdé ara wọn lọ́nà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ikọ̀ ń pàdé ara wọn, bí wọ́n ti ń sáré lọ sọ fún ọba Babiloni pé ogun ti gba ìlú rẹ̀ patapata.

32 Wọ́n ti gba ibi ìsọdá odò, wọ́n ti dáná sun àwọn ibi ààbò, ìbẹ̀rùbojo sì ti mú àwọn ọmọ ogun.

33 Babiloni dàbí ibi ìpakà, tí a tẹ̀ mọ́lẹ̀ nígbà tí à ń pa ọkà. Láìpẹ́ ọ̀tá yóo dà á wó, yóo sì di àtẹ̀mọ́lẹ̀. Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

34 “Nebukadinesari ọba Babiloni ti run Jerusalẹmu, ó ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, ó ti sọ ọ́ di ohun èlò òfìfo, ó gbé e mì bí erinmi, ó ti kó gbogbo ohun àdídùn inú rẹ̀ jẹ ní àjẹrankùn, ó ti da ìyókù nù.

35 Jẹ́ kí àwọn tí ń gbé Sioni wí pé, ‘Kí ibi tí àwọn ará Babiloni ṣe sí wa ati sí àwọn arakunrin wa dà lé wọn lórí.’ Kí àwọn ará Jerusalẹmu sì wí pé, ‘Ẹ̀jẹ̀ wa ń bẹ lórí àwọn ará ilẹ̀ Kalidea.’ ”

36 Nítorí náà, OLUWA sọ fún àwọn ará Jerusalẹmu pé, “Ẹ wò ó, n óo gba ẹjọ́ yín rò, n óo sì ba yín gbẹ̀san. N óo jẹ́ kí omi òkun Babiloni gbẹ, n óo sì jẹ́ kí orísun odò rẹ̀ gbẹ.

37 Babiloni yóo sì di òkítì àlàpà, ati ibùgbé ajáko, yóo di ibi àríbẹ̀rù ati àrípòṣé, láìsí ẹnìkan kan ninu rẹ̀.

38 Gbogbo wọn yóo bú papọ̀ bíi kinniun, wọn yóo sì ké bí àwọn ọmọ kinniun.

39 Nígbà tí ara wọn bá gbóná, n óo se àsè kan fún wọn. N óo rọ wọ́n lọ́tí yó, títí tí wọn óo fi máa yọ ayọ̀ ẹ̀sín, tí wọn óo sì sùn lọ títí ayé. Wọn óo sùn, wọn kò sì ní jí mọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

40 N óo fà wọ́n lọ sí ibi tí wọn tí ń pa ẹran, bí ọ̀dọ́ aguntan, ati àgbò ati òbúkọ.”

41 OLUWA ní, “Ẹ wò ó bí ogun ti kó Babiloni, Babiloni tí gbogbo ayé ń pọ́nlé! Ó wá di àríbẹ̀rù láàrin àwọn orílẹ̀-èdè!

42 Òkun ti ru bo Babiloni mọ́lẹ̀. Ìgbì òkun ti bò ó mọ́lẹ̀.

43 Àwọn ìlú rẹ̀ ti di àríbẹ̀rù, wọ́n ti di ilẹ̀ gbígbẹ ati aṣálẹ̀, ilẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé mọ́, tí ọmọ eniyan kò sì gbà kọjá mọ́.

44 N óo fìyà jẹ oriṣa Bẹli ní Babiloni, n óo jẹ́ kí ó pọ ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kò ní lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́, odi Babiloni pàápàá yóo wó lulẹ̀.

45 “Ẹ̀yin eniyan mi, ẹ jáde kúrò níbẹ̀! Kí olukuluku sá àsálà, kúrò lọ́wọ́ ibinu gbígbóná OLUWA!

46 Ẹ mọ́kàn, ẹ má bẹ̀rù, nítorí ìròyìn tí ẹ̀ ń gbọ́ nípa ilẹ̀ náà, nígbà tí ẹ bá gbọ́ ìròyìn kan ní ọdún yìí, tí ẹ tún gbọ́ òmíràn ní ọdún tí ń bọ̀, tí ìwà ipá sì wà ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ìjòyè sì ń dojú ìjà kọ ara wọn.

47 Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀ tí n óo fìyà jẹ àwọn ère ilẹ̀ Babiloni. Ojú yóo ti gbogbo ilẹ̀ rẹ̀, òkú àwọn eniyan rẹ̀ tí ogun yóo pa, yóo wà nílẹ̀ káàkiri ìgboro.

48 Nítorí náà, ọ̀run ati ayé, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu wọn, yóo yọ̀ nítorí ìṣubú Babiloni, nítorí pé apanirun yóo wá gbógun tì í, láti ìhà àríwá, Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

49 Bí àwọn tí ogun Babiloni pa ní àwọn orílẹ̀-èdè ayé, ti ṣubú níwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Babiloni náà gbọdọ̀ ṣubú, nítorí àwọn tí wọ́n pa ní Israẹli.”

50 OLUWA sọ fún àwọn eniyan rẹ̀ ní Babiloni pé, “Ẹ̀yin tí ẹ bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ má dúró, ẹ máa sálọ! Ẹ ranti OLUWA ní ilẹ̀ òkèèrè, kí ẹ sì máa ronú nípa Jerusalẹmu pẹlu.

51 Ẹ̀ ń sọ pé ojú ń tì yín nítorí pé wọ́n kẹ́gàn yín; ẹ ní ìtìjú dà bò yín, nítorí pé àwọn àjèjì ti wọ ibi mímọ́ ilé OLUWA.

52 Nítorí náà, èmi OLUWA ń sọ nisinsinyii pé, ọjọ́ ń bọ̀, tí n óo ṣe ìdájọ́ lórí àwọn ère rẹ̀; àwọn tí wọ́n fara gbọgbẹ́ yóo máa kérora, ní gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.

53 Bí Babiloni tilẹ̀ ga tí ó kan ojú ọ̀run, tí ó sì mọ odi yí àwọn ibi ààbò rẹ̀ gíga ká, sibẹsibẹ n óo rán apanirun sí i. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

54 OLUWA ní, “Ẹ gbọ́ igbe kan láti Babiloni! Igbe ìparun ńlá láti ilẹ̀ àwọn ará Kalidea!

55 Nítorí OLUWA ń wó Babiloni lulẹ̀, ó sì ń pa á lẹ́nu mọ́. Igbe wọn ta sókè bíi híhó omi òkun ńlá

56 nítorí pé apanirun ti dé sí i, àní ó ti dé sí Babiloni. Ogun ti kó àwọn ọmọ ogun rẹ̀, àwọn ọ̀tá ti rún àwọn ọfà rẹ̀ jégéjégé, nítorí pé Ọlọrun ẹ̀san ni èmi OLUWA, dájúdájú n óo gbẹ̀san.

57 N óo jẹ́ kí àwọn ìjòyè rẹ̀ ati àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ mu ọtí ní àmuyó, pẹlu àwọn gomina rẹ̀, àwọn ọ̀gágun rẹ̀, ati àwọn ọmọ ogun rẹ̀. Wọn yóo sun oorun àsùnrayè, wọn kò sì ní jí mọ́ laelae. Bẹ́ẹ̀ ni èmi ọba, tí orúkọ mi ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ.

58 Odi Babiloni tí ó fẹ̀, yóo wó lulẹ̀, a óo sì dáná sun àwọn ẹnubodè rẹ̀ tí ó ga fíofío. Iṣẹ́ lásán ni àwọn eniyan ń ṣe, àwọn orílẹ̀-èdè sì ń yọ ara wọn lẹ́nu lásán ni, nítorí pé iná yóo jó gbogbo làálàá wọn.”

59 Jeremaya wolii pa àṣẹ kan fún Seraaya, alabojuto ibùdó ogun, ọmọ Neraya, ọmọ Mahiseaya nígbà tí ó ń bá Sedekaya ọba Juda lọ sí Babiloni ní ọdún kẹrin ìjọba Sedekaya.

60 Jeremaya kọ gbogbo nǹkan burúkú tí yóo ṣẹlẹ̀ sí Babiloni ati gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó sọ nípa rẹ̀ sinu ìwé kan.

61 Ó bá pàṣẹ fún Seraaya pé nígbà tí ó bá dé Babiloni, kí ó rí i dájú pé ó ka gbogbo ohun tí òun kọ sinu ìwé náà sókè.

62 Kí ó sọ pé, “OLUWA, o ti sọ pé o óo pa ibí yìí run, tóbẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí nǹkankan tí yóo máa gbé inú rẹ̀ mọ́, ìbáà ṣe eniyan tabi ẹranko. O ní títí lae ni yóo di ahoro.”

63 Jeremaya ní nígbà tí Seraaya bá ka ìwé yìí tán, kí ó di òkúta kan mọ́ ọn kí ó jù ú sí ààrin odò Yufurate,

64 kí ó sì sọ wí pé, “Báyìí ni yóo rí fún Babiloni, kò sì ní gbérí mọ́, nítorí ibi tí OLUWA yóo mú kí ó dé bá a.” Ibí yìí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Jeremaya sọ parí sí.

52

1 Ẹni ọdún mọkanlelogun ni Sedekaya nígbà tí ó jọba, ọdún mọkanla ni ó sì fi wà lórí oyè ní Jerusalẹmu. Hamutali, ọmọ Jeremaya ará Libina ni ìyá rẹ̀.

2 Sedekaya ṣe nǹkan burúkú lójú OLUWA, bí Jehoiakimu ti ṣe.

3 Nǹkan tí ń ṣẹlẹ̀ ní Jerusalẹmu ati Juda burú débi pé inú fi bí OLUWA sí wọn tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi tì wọ́n jáde kúrò níwájú rẹ̀. Sedekaya ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babiloni.

4 Ní ọjọ́ kẹwaa oṣù kẹwaa, ní ọdún kẹsan-an tí Sedekaya gorí oyè, Nebukadinesari, ọba Babiloni, dé sí Jerusalẹmu pẹlu gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀. Wọ́n dó tì í, wọ́n sì mọ òkítì sí ara odi rẹ̀ yíká.

5 Wọ́n dóti ìlú náà títí di ọdún kọkanla ìjọba Sedekaya.

6 Ní ọjọ́ kẹsan-an oṣù kẹrin, ìyàn mú ní ààrin ìlú tóbẹ́ẹ̀ tí àwọn ará ìlú kò fi rí oúnjẹ jẹ mọ́.

7 Wọ́n lu odi ìlú, àwọn ọmọ ogun sì gba ibẹ̀ sá jáde lóru. Wọ́n gba ẹnu ọ̀nà tí ó wà láàrin àwọn odi meji tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọgbà ọba, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará Kalidea yí ìlú náà po, wọ́n bá dorí kọ apá ọ̀nà àfonífojì odò Jọdani.

8 Ṣugbọn àwọn ọmọ ogun Kalidea lépa ọba Sedekaya, wọ́n sì bá a ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹriko; gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ bá fọ́nká lẹ́yìn rẹ̀.

9 Ọwọ́ àwọn ọmọ ogun Kalidea tẹ Sedekaya ọba, wọ́n sì mú un lọ sọ́dọ̀ ọba Babiloni ní Ribila, ní ilẹ̀ Hamati, ọba Babiloni sì ṣe ìdájọ́ fún un.

10 Ọba Babiloni pa àwọn ọmọ Sedekaya lójú rẹ̀, ó sì pa àwọn ìjòyè Juda ní Ribila.

11 Ó yọ ojú Sedekaya mejeeji, ó fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó mú un lọ sí Babiloni, ó sì jù ú sí ọgbà ẹ̀wọ̀n, títí tí ó fi kú.

12 Ní ọjọ́ kẹwaa oṣù karun-un, ní ọdún kọkandinlogun tí Nebukadinesari ọba Babiloni jọba, Nebusaradani, olórí àwọn tí ń ṣọ́ ọba Babiloni, wọ ìlú Jerusalẹmu.

13 Ó sun ilé OLUWA níná ati ilé ọba ati gbogbo ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu; gbogbo àwọn ilé ńláńlá ní ó dáná sun.

14 Gbogbo àwọn ọmọ ogun Kalidea tí wọ́n wà pẹlu olórí àwọn tí ń ṣọ́ Nebukadinesari ọba wó gbogbo odi Jerusalẹmu lulẹ̀ patapata.

15 Nebusaradani, olórí àwọn olùṣọ́ ọba bá kó ninu àwọn talaka lẹ́rú pẹlu àwọn eniyan tí wọ́n kù ní ìlú, ati àwọn tí wọ́n ti sálọ sọ́dọ̀ ọba Babiloni, ati àwọn oníṣẹ́-ọwọ́.

16 Ṣugbọn ó ṣẹ́ àwọn díẹ̀ kù sílẹ̀ ninu àwọn talaka pé kí wọn máa ṣe ìtọ́jú ọgbà àjàrà kí wọn sì máa dá oko.

17 Àwọn ọmọ ogun Kalidea fọ́ àwọn òpó bàbà tí ó wà ninu ilé OLUWA ati agbada omi tí ó wà níbẹ̀ pẹlu ìtẹ́lẹ̀ rẹ̀. Gbogbo rẹ̀ ni wọ́n fọ́ tí wọn rún wómúwómú; wọ́n sì kó gbogbo bàbà tí ó wà ninu ilé OLUWA lọ sí Babiloni.

18 Bákan náà ni wọ́n kó àwọn ìkòkò, ọkọ́, ati àwọn ọ̀pá tí wọn fi ń pa iná ẹnu àtùpà; àwọn àwokòtò, àwọn àwo turari, ati gbogbo àwọn ohun-èlò tí wọ́n fi bàbà ṣe, tí wọn ń lò fún ìsìn ninu ilé OLUWA.

19 Wọ́n sì kó àwọn abọ́ kéékèèké, àwọn àwo ìfọnná, ati àwọn àwokòtò; àwọn ìkòkò, àwọn ọ̀pá fìtílà, ati àwọn àwo turari, ati àwọn abọ́ tí wọ́n fi ń ta ohun mímu sílẹ̀. Gbogbo nǹkan èlò tí wọ́n fi wúrà ati fadaka ṣe ni Nebusaradani, olórí àwọn tí wọn ń ṣọ́ ọba Babiloni kó lọ.

20 Bàbà tí Solomoni fi ṣe òpó mejeeji ati agbada omi, pẹlu àwọn mààlúù idẹ mejeejila tí wọ́n gbé agbada náà dúró, ati àwọn ìtẹ́lẹ̀ tí Solomoni ọba ṣe fún ilé OLUWA kọjá wíwọ̀n.

21 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ninu àwọn òpó náà ga ní igbọnwọ mejidinlogun, àyíká wọn jẹ́ igbọnwọ mejila, wọ́n nípọn, ní ìka mẹrin, wọ́n sì ní ihò ninu.

22 Ọpọ́n idẹ orí rẹ̀ ga ní igbọnwọ marun-un, wọ́n ṣe ẹ̀wọ̀n bí ẹ̀gbà ọrùn ati èso Pomegiranate yí ọpọ́n náà ká.

23 Òpó keji rí bákan náà pẹlu èso Pomegiranate. Mẹrindinlọgọrun-un ni àwọn èso Pomegiranate tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kọ̀ọ̀kan; ọgọrun-un ni gbogbo èso Pomegiranate tí ó wà ní àyíká ẹ̀wọ̀n náà.

24 Olórí àwọn tí wọn ń ṣọ́ ọba Babiloni mú Seraaya, olórí alufaa ati Sefanaya tí ó jẹ́ igbákejì rẹ̀ ati àwọn aṣọ́nà mẹtẹẹta.

25 Ó sì mú ọ̀gágun tí ń ṣe àkóso àwọn ọmọ ogun, ati meje ninu àwọn aṣojú ọba tí wọn rí láàrin ìlú ati akọ̀wé olórí ogun tí ń kọ orúkọ àwọn eniyan sílẹ̀ fún ogun jíjà. Wọ́n tún kó ọgọta eniyan ninu àwọn ará ìlú tí wọn rí láàrin ìgboro.

26 Nebusaradani olórí àwọn tí wọn ń ṣọ́ ọba, kó wọn lọ sọ́dọ̀ ọba Babiloni ní Ribila.

27 Ọba Babiloni sì pa wọ́n ní Ribila ní ilẹ̀ Hamati. Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe kó àwọn eniyan Juda ní ìgbèkùn kúrò ní ilẹ̀ wọn.

28 Iye àwọn eniyan tí Nebukadinesari kó lọ sí ìgbèkùn nìwọ̀nyí ní ọdún keje tí ó jọba, ó kó ẹgbẹẹdogun ó lé mẹtalelogun (3,023) lára àwọn Juu.

29 Ní ọdún kejidinlogun, ó kó àwọn ẹgbẹrin ó lé mejilelọgbọn (832) eniyan ní Jerusalẹmu.

30 Ní ọdún kẹtalelogun tí Nebukadinesari jọba, Nebusaradani, olórí àwọn tí wọn ń ṣọ́ ọba, kó ojilelẹẹdẹgbẹrin ó lé marun-un (745) eniyan lára àwọn Juu. Gbogbo àwọn eniyan tí wọn kó lẹ́rú jẹ́ ẹgbaaji lé ẹgbẹta (4,600).

31 Ní ọdún kẹtadinlogoji lẹ́yìn tí a ti mú Jehoiakini, ọba Juda lọ sí ìgbèkùn, ní ọjọ́ kẹẹdọgbọn oṣù kejila ọdún náà Efilimerodaki, ọba Babiloni yẹ ọ̀rọ̀ Jehoiakini wò ní ọdún tí ó gorí oyè, ó sì pàṣẹ pé kí á tú u sílẹ̀ kúrò ní àtìmọ́lé.

32 Ó bá a sọ ọ̀rọ̀ rere, ó sì fi sí ipò tí ó ga jùlọ, àní ipò tí ó ga ju ti gbogbo àwọn ọba tí wọ́n wà pẹlu rẹ̀ ní Babiloni lọ.

33 Jehoiakini bọ́ aṣọ ẹ̀wọ̀n kúrò lọ́rùn, ó sì ń bá ọba jẹun lórí tabili ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

34 Ọba Babiloni sì rí i pé òun ń pèsè gbogbo ohun tí ó nílò lojoojumọ fún un títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.