1 Ìran tí Aisaya ọmọ Amosi rí sí Juda ati Jerusalẹmu nìyí, nígbà ayé Usaya, Jotamu, Ahasi, ati Hesekaya, àwọn ọba Juda.
2 Máa gbọ́, ìwọ ọ̀run, sì fetí sílẹ̀, ìwọ ayé Nítorí pé OLUWA ń sọ̀rọ̀ Ó ní, “Lẹ́yìn tí mo bọ́ àwọn ọmọ, tí mo tọ́ wọn dàgbà tán, ọ̀tẹ̀ ni wọ́n dì sí mi.
3 Mààlúù mọ olówó rẹ̀; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sí mọ ibùjẹ tí oluwa rẹ̀ ṣe fún un; ṣugbọn Israẹli kò mọ nǹkan, òye kò yé àwọn eniyan mi.”
4 Háà! Orílẹ̀-èdè tí ó kún fún ẹ̀ṣẹ̀, àwọn eniyan tí ẹrù ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lọ, ìran oníṣẹ́ ibi; àwọn ọmọ tí ó kún fún ìwà ìbàjẹ́! Wọ́n ti kọ OLUWA sílẹ̀, wọn kò náání Ẹni Mímọ́ Israẹli wọ́n sì ti kẹ̀yìn sí i.
5 Ṣé ẹ fẹ́ kí á tún jẹ yín níyà sí i ni, àbí kí ló dé tí ẹ kò fi jáwọ́ ninu ìwà ọ̀tẹ̀ tí ẹ̀ ń hù? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkìdá egbò, gbogbo ọkàn yín sì rẹ̀wẹ̀sì.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ dé orí yín, kò síbìkan tí ó gbádùn. Gbogbo ara yín kún fún ọgbẹ́ ati egbò tí ń ṣẹ̀jẹ̀. Ẹnikẹ́ni kò wẹ egbò yín, wọn kò dì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi òògùn sí wọn.
7 Orílẹ̀-èdè yín ti di ahoro, wọ́n ti dáná sun àwọn ìlú yín. Àwọn àjèjì sì ti jẹ ilẹ̀ yín run níṣojú yín. Ó di ahoro bí èyí tí àwọn àjèjì wó palẹ̀.
8 Ó wá ku Jerusalẹmu bí àtíbàbà ninu ọgbà àjàrà, ati bí ahéré ninu oko ẹ̀gúsí; ó wá dàbí ìlú tí ogun dótì.
9 Bí kò bá ṣe pé OLUWA àwọn ọmọ ogun dá díẹ̀ sí ninu wa ni, à bá rí bí i Sodomu, à bá sì dàbí Gomora.
10 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ̀yin ìjòyè Sodomu: Ẹ fetí sí ẹ̀kọ́ Ọlọrun wa, ẹ̀yin ará Gomora
11 OLUWA ní, “Kí ni gbogbo ẹbọ yín jámọ́ fún mi? Àgbò tí ẹ fi ń rú ẹbọ sísun sí mi ti tó gẹ́ẹ́; bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọ̀rá ẹran àbọ́pa. N kò ní inú dídùn sí ẹ̀jẹ̀ mààlúù tabi ti ọ̀dọ́ aguntan tabi ti òbúkọ.
12 Nígbà tí ẹ bá wá jọ́sìn níwájú mi, ta ló bẹ̀ yín ní gbogbo gìrìgìrì lásán, tí ẹ̀ ń dà ninu àgbàlá mi.
13 Ẹ má mú ẹbọ asán wá fún mi mọ́; ohun ìríra ni turari jẹ́ fún mi. Àjọ̀dún ìbẹ̀rẹ̀ oṣù titun, ọjọ́ ìsinmi, ati pípe àpéjọ. Ara mi kò gba ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ̀ ń dàpọ̀ mọ́ ẹ̀sìn mọ́.
14 Ninu ọkàn mi, mo kórìíra àwọn àjọ̀dún oṣù tuntun yín, ati àwọn àjọ̀dún pataki yín. Wọ́n ti di ẹrù wúwo fún mi, n kò lè gbé e mọ́, ó sú mi.
15 “Bí ẹ bá tẹ́wọ́ adura, n óo gbé ojú mi kúrò lọ́dọ̀ yín. Ẹ̀ báà tilẹ̀ gbadura, gbadura n kò ní gbọ́; nítorí ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀,
16 Ẹ wẹ̀, kí ara yín dá ṣáká. Ẹ má hùwà burúkú níwájú mi mọ́. Ẹ má ṣe iṣẹ́ ibi mọ́.
17 Ẹ lọ kọ́ bí eniyan tí ń ṣe rere. Ẹ máa ṣe ẹ̀tọ́. Ẹ máa ran ẹni tí ara ń ni lọ́wọ́. Ẹ máa gbìjà aláìníbaba, kí ẹ sì máa gba ẹjọ́ opó rò.”
18 OLUWA ní, “Ẹ wá ná, ẹ jẹ́ kí á jọ sọ àsọyé pọ̀. Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín tilẹ̀ pọ́n bí iná, yóo di funfun bí ẹfun. Bí ó tilẹ̀ pupa bí aṣọ àlàárì, yóo di funfun bí irun ọmọ aguntan funfun.
19 Bí ẹ bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́ràn, ẹ óo jẹ ire ilẹ̀ náà.
20 Ṣugbọn tí ẹ bá kọ̀, tí ẹ sì ṣoríkunkun; idà ni yóo run yín.” Bẹ́ẹ̀ ni OLUWA sọ.
21 Ìlú tí ó ti jẹ́ olódodo rí tí ń ṣe bí aṣẹ́wó, ìlú tí ó ti kún fún ẹ̀tọ́ ati òdodo rí, ti kún fún ìpànìyàn.
22 Fadaka rẹ ti di ìdàrọ́ mọ́ ọ lọ́wọ́. Wọ́n ti fi omi lú ọtí waini rẹ.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn ìjòyè rẹ, ati ẹgbẹ́ olè; gbogbo wọn ni wọ́n fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí wọn sì ń wá ẹ̀bùn káàkiri. Wọn kì í gbèjà aláìníbaba, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í gba ẹjọ́ opó rò.
24 Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Alágbára Israẹli ní: “N óo bínú sí àwọn ọ̀tá mi, n óo sì gbẹ̀san lára àwọn tí ó kórìíra mi.
25 Nígbà tí mo bá gbá ọ mú, n óo finá jó gbogbo àìdára rẹ dànù. N óo sì mú gbogbo ìbàjẹ́ rẹ kúrò.
26 N óo dá àwọn onídàájọ́ rẹ pada sí ipò tí wọn ti wà tẹ́lẹ̀. Ati àwọn olùdámọ̀ràn rẹ, lẹ́yìn náà a óo máa pè ọ́ ní ìlú olódodo.”
27 A óo fi ẹ̀tọ́ ra Sioni pada; a óo sì fi òdodo ra àwọn tí ó bá ronupiwada ninu rẹ pada.
28 Ṣugbọn a óo pa àwọn ọlọ̀tẹ̀ ati àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ run, àwọn tí ó kọ OLUWA sílẹ̀ yóo sì ṣègbé.
29 Ojú yóo tì yín, fún àwọn igi Oaku tí ẹ nífẹ̀ẹ́ láti máa bọ. Ojú yóo sì tì yín fún àwọn ọgbà oriṣa tí ẹ yàn.
30 Nítorí pé ẹ óo dàbí igi oaku tí ó wọ́wé, ati bí ọgbà tí kò lómi.
31 Alágbára yóo dàbí ògùṣọ̀, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ bí ìṣáná. Àwọn mejeeji ni yóo jóná pọ̀, kò sì ní sí ẹni tí yóo lè pa iná náà.
1 Ọ̀rọ̀ tí Aisaya ọmọ Amosi sọ nípa Juda ati Jerusalẹmu nìyí:
2 Ní ọjọ́ iwájú òkè ilé OLUWA yóo fi ìdí múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òkè tí ó ga jùlọ, a óo sì gbé e ga ju àwọn òkè yòókù lọ. Gbogbo orílẹ̀-èdè yóo wá sibẹ.
3 Ọpọlọpọ eniyan ni yóo wá, tí wọn yóo máa wí pé: “Ẹ wá! Ẹ jẹ́ kí á gun òkè OLUWA lọ, kí á lọ sí ilé Ọlọrun Jakọbu, kí ó lè kọ́ wa ní ìlànà rẹ̀, kí á sì lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀. Nítorí pé láti Sioni ni òfin Ọlọrun yóo ti jáde wá ọ̀rọ̀ OLUWA yóo sì wá láti Jerusalẹmu.”
4 Yóo ṣe ìdájọ́ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè; yóo sì bá ọpọlọpọ eniyan wí. Wọn yóo fi idà wọn rọ ọkọ́, wọn yóo sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Àwọn orílẹ̀-èdè kò ní yọ idà sí ara wọn mọ́, wọn kò sì ní kọ́ ogun jíjà mọ́.
5 Ẹ̀yin ìdílé Jakọbu ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á rìn ninu ìmọ́lẹ̀ OLUWA.
6 Nítorí o ti ta àwọn eniyan rẹ nù, àní, ìdílé Jakọbu. Nítorí pé àwọn aláfọ̀ṣẹ ará ìhà ìlà oòrùn pọ̀ láàrin wọn, àwọn alásọtẹ́lẹ̀ sì pọ̀ bíi ti àwọn ará Filistini, Wọ́n ti gba àṣà àwọn àjèjì.
7 Wúrà ati fadaka kún ilẹ̀ wọn, ìṣúra wọn kò sì lópin. Ẹṣin kún ilẹ̀ wọn, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lóǹkà.
8 Ilẹ̀ wọn kún fún oriṣa, wọ́n ń bọ iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, wọ́n ń wólẹ̀ fún ohun tí wọ́n fọwọ́ ara wọn ṣe.
9 Bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe tẹ ara rẹ̀ lórí ba tí ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀. Oluwa, máṣe dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.
10 Ẹ wọnú àpáta lọ, kí ẹ sì farapamọ́ sinu ilẹ̀. Ẹ sá fún ibinu OLUWA ati ògo ọlá ńlá rẹ̀.
11 A óo rẹ ọlọ́kàn gíga eniyan sílẹ̀, a óo sì rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀; OLUWA nìkan ni a óo gbéga ní ọjọ́ náà.
12 Nítorí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀, tí yóo dojú ìjà kọ àwọn agbéraga, ati àwọn ọlọ́kàn gíga, ati gbogbo nǹkan tí à ń gbéga.
13 Yóo dojú kọ gbogbo igi Kedari ti Lẹbanoni, tí ó ga fíofío, ati gbogbo igi oaku ilẹ̀ Baṣani;
14 ati gbogbo àwọn òkè ńláńlá, ati gbogbo òkè gíga,
15 ati gbogbo ilé-ìṣọ́ gíga ati gbogbo odi tí ó lágbára,
16 ati gbogbo ọkọ̀ ojú omi láti ìlú Taṣiṣi, ati gbogbo ọkọ̀ tí ó dára.
17 Àwọn ọlọ́kàn gíga yóo di ẹni ilẹ̀, a óo sì rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀. OLUWA nìkan ni a óo gbéga ní ọjọ́ náà,
18 àwọn oriṣa yóo sì pòórá patapata.
19 Àwọn eniyan yóo sá sinu ihò àpáta, wọn yóo sì wọ inú ihò ilẹ̀ lọ, nígbà tí wọ́n bá ń sá fún ibinu OLUWA, ati ògo ọlá ńlá rẹ̀ nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn eniyan óo kó àwọn ère fadaka wọn dànù, ati àwọn ère wúrà tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe, tí wọn tún ń bọ. Wọn yóo dà wọ́n fún àwọn èkúté ati àwọn àdán.
21 Wọn óo wọ inú pàlàpálá àpáta, ati inú ihò àwọn òkè gíga; nígbà tí wọn bá ń sá fún ibinu OLUWA, ati ògo ọlá ńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
22 Ẹ má gbẹ́kẹ̀lé eniyan mọ́. Ẹlẹ́mìí ni òun alára, nítorí pé kí ni ó lè ṣe?
1 Wò ó! OLUWA, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo mú gbogbo àwọn tí àwọn eniyan gbójúlé kúrò, ati àwọn nǹkan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ní Jerusalẹmu ati Juda. Yóo gba gbogbo oúnjẹ tí wọ́n gbójúlé, ati gbogbo omi tí wọ́n fi ẹ̀mí tẹ̀.
2 Yóo mú àwọn alágbára ati àwọn ọmọ ogun kúrò, pẹlu àwọn onídàájọ́ ati àwọn wolii, àwọn aláfọ̀ṣẹ ati àwọn àgbààgbà;
3 àwọn olórí aadọta ọmọ ogun, ati àwọn ọlọ́lá, àwọn adáhunṣe ati àwọn pidánpidán, ati àwọn olóògùn.
4 Ọdọmọkunrin ni OLUWA yóo fi jẹ olórí wọn, àwọn ọmọde ni yóo sì máa darí wọn.
5 Àwọn eniyan náà yóo máa fìyà jẹ ara wọn, olukuluku yóo máa fìyà jẹ ẹnìkejì rẹ̀, àwọn aládùúgbò yóo sì máa fìyà jẹ ara wọn. Ọmọde yóo nàró mọ́ àgbàlagbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóo máa dìde sí àwọn ọlọ́lá.
6 Nígbà tí ẹnìkan bá dì mọ́ arakunrin rẹ̀, ninu ilẹ̀ baba rẹ̀, tí ó sọ fún un pé, “Ìwọ ní aṣọ ìlékè, nítorí náà, jẹ́ olórí fún wa; gbogbo ahoro yìí yóo sì wà lábẹ́ àkóso rẹ.”
7 Ní ọjọ́ náà, ẹni tí wọn sọ pé kí ó jẹ olórí yóo kígbe pé, “Èmi kò ní jẹ oyè alátùn-únṣe. N kò ní oúnjẹ nílé bẹ́ẹ̀ ni kò sí aṣọ. Ẹ má fi mí ṣe olórí yín.”
8 Nítorí Jerusalẹmu ti kọsẹ̀, Juda sì ti ṣubú. Nítorí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ati ìṣe wọn lòdì sí OLUWA, wọ́n ń tàpá sí ògo wíwà rẹ̀.
9 Ìwà àgàbàgebè wọn ń takò wọ́n; wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bíi ti Sodomu: Wọn kò fi bò rárá. Ègbé ni fún wọn, nítorí pé àwọn ni wọ́n mú ibi wá sórí ara wọn.
10 Sọ fún àwọn olódodo pé yóo dára fún wọn nítorí wọn yóo jèrè iṣẹ́ wọn.
11 Ègbé ni fún àwọn eniyan burúkú, kò ní dára fún wọn. Nítorí wọn óo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
12 Ẹ wá wo àwọn eniyan mi! Ọmọde ni àwọn olórí àwọn eniyan mi; àwọn obinrin ní ń pàṣẹ lé wọn lórí. Ẹ̀yin eniyan mi, àwọn olórí yín ń ṣì yín lọ́nà, wọ́n sì ti da ọ̀nà yín rú.
13 OLUWA ti dìde láti ro ẹjọ́ tirẹ̀; ó ti múra tán láti dá àwọn eniyan rẹ̀ lẹ́jọ́
14 OLUWA yóo pe àwọn àgbààgbà ati àwọn olórí àwọn eniyan rẹ̀ siwaju ìtẹ́ ìdájọ́, yóo sọ fún wọn pé; “Ẹ̀yin ni ẹ jẹ ọgbà àjàrà mi run, ohun tí ẹ jí nílé àwọn talaka ń bẹ nílé yín.
15 Kí ni ẹ rò tí ẹ fi ń tẹ àwọn eniyan mi ní àtẹ̀rẹ́, tí ẹ̀ ń fi ojú àwọn talaka gbolẹ̀?”
16 OLUWA ní, “Nítorí pé àwọn obinrin Jerusalẹmu jẹ́ onigbeeraga, bí wọn bá ń rìn, wọn á gbé ọrùn sókè gangan; wọn á máa ṣẹ́jú bí wọn tí ń yan lọ. Ṣaworo tí ó wà lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn a sì máa dún bí wọ́n tí ń gbésẹ̀ lọ́kọ̀ọ̀kan.
17 OLUWA yóo mú kí orí àwọn obinrin Jerusalẹmu pá; yóo ṣí aṣọ lórí wọn.”
18 Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo já gbogbo nǹkan ọ̀ṣọ́ wọn dànù; ati ṣaworo ẹsẹ̀ wọn ni, ati ẹ̀gbà orí wọn; ẹ̀gbà ọrùn wọn;
19 ati yẹtí wọn, ẹ̀gbà ọwọ́ wọn ati ìbòrí wọn.
20 Gèlè wọn ati ìlẹ̀kẹ̀ ẹsẹ̀ wọn, ati ìborùn, ìgò ìpara wọn ati òògùn,
21 òrùka ọwọ́ wọn ati òrùka imú,
22 ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ ati ẹ̀wù àwọ̀lékè ati aṣọ wọn, ati àpò
23 ati àwọn aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ funfun, àwọn ìborùn olówó ńlá.
24 Òórùn burúkú yóo wà dípò òórùn dídùn ìpara, okùn yóo wà dípò ọ̀já; orí pípá yóo dípò irun tí wọ́n ṣe lọ́ṣọ̀ọ́, aṣọ ọ̀fọ̀ yóo dípò aṣọ olówó iyebíye. Ìtìjú yóo bò yín dípò ẹwà.
25 Idà ni yóo pa àwọn ọkunrin yín, àwọn akikanju yín yóo kú sógun.
26 Ọ̀fọ̀ ati ẹkún yóo pọ̀ ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu. Yóo dàbí obinrin tí wọ́n tú sí ìhòòhò, tí ó jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀.
1 Tí ó bá di ìgbà náà, obinrin meje yóo rọ̀ mọ́ ọkunrin kan ṣoṣo, wọn óo máa bẹ̀ ẹ́ pé, “A óo máa bọ́ ara wa, a óo sì máa dá aṣọ sí ara wa lọ́rùn. Ṣá máa jẹ́ ọkọ wa, kí á máa jẹ́ orúkọ rẹ; kí o mú ìtìjú kúrò lọ́rọ̀ wa.”
2 Tí ó bá di ìgbà náà, ẹ̀ka igi OLUWA yóo di ohun ẹwà ati iyì. Èso ilẹ̀ náà yóo sì di ohun ògo ati àmúyangàn fún àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n bá kù.
3 Eniyan mímọ́ ni a óo máa pe àwọn tí wọ́n bá kù ní Sioni, àní, àwọn tí wọ́n ṣẹ́kù ní Jerusalẹmu; gbogbo àwọn tí a bá kọ orúkọ wọn sílẹ̀ pé wọ́n wà láàyè ní Jerusalẹmu.
4 Nígbà tí OLUWA bá ti fọ èérí Jerusalẹmu dànù, tí ó sì jó o níná tí ó sì mú ẹ̀bi ìpànìyàn kúrò níbẹ̀, nípa pé kí wọn máa ṣe ìdájọ́ òtítọ́,
5 ní ọ̀sán, yóo mú kí ìkùukùu bo gbogbo òkè Sioni ati àwọn tí ó ń péjọ níbẹ̀; ní alẹ́, yóo sì fi èéfín ati ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ bò wọ́n. Ògo OLUWA yóo bò wọ́n bí àtíbàbà ati ìbòrí.
6 Yóo dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ oòrùn lọ́sàn-án, yóo jẹ́ ibi ìsásí ati ààbò fún wọn lọ́wọ́ ìjì ati òjò.
1 Ẹ jẹ́ kí n kọrin kan fún olùfẹ́ mi, kí n kọrin nípa ọgbà àjàrà rẹ̀. Olùfẹ́ mi ní ọgbà àjàrà kan ní orí òkè kan tí ilẹ̀ ibẹ̀ lọ́ràá.
2 Ó kọ́ ilẹ̀ rẹ̀, ó sì ṣa gbogbo òkúta ibẹ̀ kúrò. Ó gbin àjàrà dáradára sinu rẹ̀. Ó kọ́ ilé ìṣọ́ gíga sí ààrin rẹ̀, ó sì ṣe ibi tí wọn yóo ti máa fún ọtí sibẹ. Ó ń retí kí àjàrà rẹ̀ so, ṣugbọn èso kíkan ni ó so.
3 Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ati ẹ̀yin ará Juda, mo bẹ̀ yín, ẹ wá ṣe ìdájọ́ láàrin èmi ati ọgbà àjàrà mi.
4 Kí ló tún kù tí ó yẹ kí n ṣe sí ọgbà àjàrà mi tí n kò ṣe? Ìgbà tí mo retí kí ó so èso dídùn, kí ló dé tí ó fi so èso kíkan?
5 Nisinsinyii n óo sọ ohun tí n óo ṣe sí ọgbà àjàrà mi fun yín. N óo tú ọgbà tí mo ṣe yí i ká, iná yóo sì jó o. N óo wó odi tí mo mọ yí i ká, wọn yóo sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀.
6 N óo jẹ́ kí ó di igbó, ẹnikẹ́ni kò ní ro ó mọ́, wọn kò sì ní tọ́jú rẹ̀ mọ́. Ẹ̀gún ati ẹ̀wọ̀n agogo ni yóo hù níbẹ̀. N óo pàṣẹ fún òjò kí ó má rọ̀ sórí rẹ̀ mọ́.
7 Nítorí ilé Israẹli ni ọgbà àjàrà OLUWA ọmọ ogun, àwọn ará Juda ni àjàrà dáradára tí ó gbìn sinu rẹ̀. Ó ń retí kí wọn máa ṣe ẹ̀tọ́, ṣugbọn kàkà bẹ́ẹ̀ wọ́n ń paniyan; ó ń retí ìwà òdodo, ṣugbọn kàkà bẹ́ẹ̀, àwọn tí wọn ń ni lára ni wọ́n ń kígbe.
8 Ègbé ni fún àwọn tí ó ń kọ́lé mọ́lé, tí wọn ń gba ilẹ̀ kún ilẹ̀, títí tí kò fi sí ilẹ̀ mọ́, kí ẹ̀yin nìkan baà lè máa gbé ilẹ̀ náà.
9 OLUWA ọmọ ogun ti búra lójú mi, ó ní, “Láìsí àní-àní, ọpọlọpọ ilé ni yóo di ahoro, ọ̀pọ̀ ilé ńláńlá, ati ilé dáradára yóo sì wà láìsí olùgbé.
10 Apẹ̀rẹ̀ èso àjàrà kan ni a óo rí ká ninu ọgbà àjàrà sarè mẹ́wàá. Kóńgò èso kan ni ẹni tí ó gbin kóńgò marun-un yóo rí ká.”
11 Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n jí ní òwúrọ̀ kutukutu, láti máa wá ọtí líle kiri, tí wọ́n ń mu ún títí di ìrọ̀lẹ́, títí tí ọtí yóo fi máa pa wọ́n!
12 Dùùrù, hapu, ìlù, fèrè ati ọtí waini wà níbi àsè wọn; ṣugbọn wọn kì í bìkítà fún iṣẹ́ Ọlọrun, wọn kìí sìí náání iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
13 Nítorí náà àwọn eniyan mi óo lọ sí oko ẹrú nítorí àìmòye wọn, ebi ni yóo pa àwọn ọlọ́lá wọn ní àpakú, òùngbẹ óo sì gbẹ ọpọlọpọ wọn.
14 Isà òkú ti ṣetán, yóo gbé wọn mì, ó ti yanu kalẹ̀. Àwọn ọlọ́lá Jerusalẹmu yóo já sinu rẹ́, ati ọ̀pọ̀ ninu àwọn ará ìlú, ati àwọn tí ń fi ìlú Jerusalẹmu yangàn.
15 A tẹ eniyan lórí ba, a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀ ojú àwọn onigbeeraga yóo sì wálẹ̀.
16 Ṣugbọn OLUWA àwọn ọmọ ogun ni a óo gbéga ninu ẹ̀tọ́ nítorí ìdájọ́ òdodo Ọlọrun Mímọ́ yóo fi ara rẹ̀ hàn, pé mímọ́ ni òun ninu òdodo.
17 Nígbà náà ni àwọn ọ̀dọ́ aguntan yóo máa jẹ oko ninu pápá oko wọn àwọn àgbò ati ewúrẹ́ yóo sì máa jẹko ninu ahoro wọn.
18 Àwọn tí ń ṣe àfọwọ́fà ẹ̀ṣẹ̀ gbé! Àwọn tí wọn ń fi ìwà aiṣododo fa ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni tí ń fi okùn fa ẹṣin.
19 Tí wọn ń wí pé: “Kí ó tilẹ̀ ṣe kíá, kí ó ṣe ohun tí yóo ṣe, kí á rí i. Jẹ́ kí àbá Ẹni Mímọ́ Israẹli di òtítọ́ kí ó ṣẹlẹ̀, kí á lè mọ̀ ọ́n!”
20 Àwọn tí ń pe ibi ní ire gbé; tí wọn ń pe ire ní ibi! Àwọn tí wọn ń fi òkùnkùn ṣe ìmọ́lẹ̀, tí wọn sì fi ìmọ́lẹ̀ ṣe òkùnkùn! Tí wọ́n fi ìkorò ṣe adùn, tí wọ́n sì fi adùn ṣe ìkorò.
21 Àwọn tí ó gbọ́n lójú ara wọn gbé; tí wọ́n ka ara wọn kún ẹni tí ó ní ìmọ̀!
22 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọ̀gá ninu ọtí mímu gbé; tí wọ́n jẹ́ akikanju bí ó bá di pé kí á da ọtí líle pọ̀ mọ́ ara wọn!
23 Àwọn tí wọn ń dá ẹni tí ó jẹ̀bi sílẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ti gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tán; tí wọn kì í jẹ́ kí aláìṣẹ̀ rí ẹ̀tọ́ gbà.
24 Nítorí náà, bí iná tíí jó àgékù igi kanlẹ̀, tíí sìí jó ewéko ní àjórun; bẹ́ẹ̀ ní gbòǹgbò wọn yóo ṣe rà, tí ìtànná wọn yóo sì fẹ́ lọ bí eruku. Nítorí wọ́n kọ òfin OLUWA àwọn ọmọ ogun sílẹ̀, wọ́n sì kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́ Israẹli.
25 Nítorí náà ni inú ṣe bí OLUWA sí àwọn eniyan rẹ̀, ó sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì pa wọ́n, àwọn òkè sì mì tìtì. Òkú wọn dàbí pàǹtí láàrin ìgboro, sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì dá ọwọ́ ìjà dúró.
26 Ó ta àsíá, ó fi pe orílẹ̀-èdè kan tí ó wà ní òkèèrè; ó sì fọn fèrè sí i láti òpin ayé. Wò ó! Àwọn eniyan orílẹ̀-èdè náà ń bọ̀ kíákíá.
27 Kò rẹ ẹnikẹ́ni ninu wọn, ẹnikẹ́ni ninu wọn kò fẹsẹ̀ kọ. Ẹyọ ẹnìkan wọn kò sì sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tòògbé. Àmùrè ẹnìkankan kò tú, bẹ́ẹ̀ ni okùn bàtà ẹnìkankan kò já.
28 Ọfà wọn mú wọ́n kẹ́ ọrun wọn. Pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin wọn le bí òkúta akọ; ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn dàbí ìjì líle.
29 Bíbú wọn dàbí ti kinniun, wọn a bú ramúramù bí ọmọ kinniun, wọn a kígbe, wọn a sì ki ohun ọdẹ wọn mọ́lẹ̀, wọn a gbé e lọ, láìsí ẹni tí ó lè gbà á lọ́wọ́ wọn.
30 Wọn óo hó lé Israẹli lórí lọ́jọ́ náà bí ìgbà tí omi òkun ń hó. Bí eniyan bá wọ ilẹ̀ náà yóo rí òkùnkùn ati ìnira. Ìkùukùu rẹ̀ yóo sì bo ìmọ́lẹ̀.
1 Ní ọdún tí Usaya Ọba kú, mo rí OLUWA: ó jókòó lórí ìtẹ́, a gbé e ga sókè, aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
2 Àwọn Serafu dúró lókè rẹ̀. Ọ̀kọ̀ọ̀kan ninu wọn ní ìyẹ́ mẹfa mẹfa: ó fi meji bo ojú, ó fi meji bo ẹsẹ̀, ó sì ń fi meji fò.
3 Ekinni ń ké sí ekeji pé: “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni OLUWA àwọn ọmọ ogun; gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
4 Ìpìlẹ̀ ilé náà mì títí nígbà tí ẹni náà kígbe, èéfín sì kún ilé náà.
5 Mo bá pariwo, mo ní, “Mo gbé! Mo ti sọnù, nítorí pé ọ̀rọ̀ ẹnu mi kò mọ́, ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn tí mò ń gbé ààrin wọn náà kò sì mọ́. Bẹ́ẹ̀ sì ni mo ti fi ojú rí Ọba, OLUWA àwọn ọmọ ogun.”
6 Ọ̀kan ninu àwọn Serafu náà bá fi ẹ̀mú mú ẹ̀yinná kan lórí pẹpẹ, ó mú un lọ́wọ́, ó bá fò wá sọ́dọ̀ mi.
7 Ó sì fi ògúnná náà kàn mí lẹ́nu, ó ní: “Wò ó, èyí ti kàn ọ́ ní ètè: A ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
8 Mo wá gbọ́ ohùn OLUWA ó ní, “Ta ni kí n rán? Ta ni yóo lọ fún wa?” Mo bá dáhùn, mo ní: “Èmi nìyí, rán mi.”
9 OLUWA bá ní: “Lọ, sọ fún àwọn eniyan wọnyi pé; wọn óo gbọ́ títí, ṣugbọn kò ní yé wọn; wọn óo wò títí, ṣugbọn wọn kò ní rí nǹkankan.
10 Mú kí ọkàn àwọn eniyan wọnyi ó yigbì, jẹ́ kí etí wọn di. Fi nǹkan bò wọ́n lójú, kí wọn má baà ríran, kí wọn má sì gbọ́ràn, kí òye má baà yé wọn, kí wọn má baà yipada, kí wọn sì rí ìwòsàn.”
11 Mo bá bi í pé: “OLUWA mi, títí di ìgbà wo?” Ó sì dáhùn pé: “Títí tí àwọn ìlú yóo fi di ahoro, láìsí ẹni tí yóo máa gbé inú wọn; títí tí ilé yóo fi tú láì ku ẹnìkan, títí tí ilẹ̀ náà yóo fi di ahoro patapata.
12 Tí OLUWA yóo kó àwọn eniyan lọ sí ilẹ̀ òkèèrè, tí ibi tí a kọ̀tì yóo sì di pupọ ní ilẹ̀ náà.
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá àwọn eniyan náà ni ó kù ní ilẹ̀ náà, sibẹsibẹ iná yóo tún jó o bí igi terebinti tabi igi Oaku, tí kùkùté rẹ̀ wà lórí ilẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n gé e lulẹ̀.” Èso mímọ́ ni kùkùté rẹ̀.
1 Nígbà ayé Ahasi, ọmọ Jotamu, ọmọ Usaya, ọba Juda, Resini Ọba Siria ati Peka ọmọ Remalaya, ọba Israẹli wá gbé ogun ti Jerusalẹmu, ṣugbọn wọn kò lè ṣẹgun rẹ̀.
2 Nígbà tí ìròyìn dé ilé ọba Dafidi pé àwọn ará Siria ati Efuraimu ń gbógun bọ̀, ọkàn òun ati àwọn eniyan rẹ̀ mì tìtì bí afẹ́fẹ́ tíí mi igi ninu igbó.
3 OLUWA sọ fún Aisaya pé, “Lọ bá Ahasi, ìwọ ati Ṣeari Jaṣubu, ọmọ rẹ, ní òpin ibi tí wọ́n fa omi dé ní ọ̀nà àwọn alágbàfọ̀.
4 Kí o sọ fún un pé, ṣọ́ra, farabalẹ̀, má sì bẹ̀rù. Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ já rárá nítorí ibinu gbígbóná Resini ati Siria, ati ti ọmọ Remalaya, nítorí wọn kò yàtọ̀ sí àjókù igi iná meji tí ń rú èéfín.
5 Nítorí pé Siria, pẹlu Efuraimu ati ọmọ Remalaya ti pète ati ṣe ọ́ ní ibi. Wọ́n ń sọ pé,
6 ‘Ẹ jẹ́ kí á lọ gbógun ti Juda, kí á dẹ́rùbà á, ẹ jẹ́ kí á ṣẹgun rẹ̀ kí á sì gbà á, kí á fi ọmọ Tabeeli jọba lórí rẹ̀!’
7 “Àbá tí wọn ń dá kò ní ṣẹ, ète tí wọn ń pa kò ní rí bẹ́ẹ̀.
8 Ṣebí Damasku ni olú-ìlú Siria, Resini sì ni olórí Damasku. Láàrin ìsinyìí sí ọdún marundinlaadọrin, Efuraimu yóo fọ́nká, kò sì ní jẹ́ orílẹ̀-èdè mọ́.
9 Ṣebí Samaria ni olú-ìlú Efuraimu, Ọmọ Remalaya sì ni olórí Samaria. Bí ẹ kò bá gbàgbọ́ ẹ kò ní fẹsẹ̀ múlẹ̀.”
10 OLUWA tún sọ fún Ahasi pé:
11 “Bèèrè àmì tí ó bá wù ọ́ lọ́wọ́ OLUWA Ọlọrun rẹ–ìbáà jìn bí isà òkú, tabi kí ó ga bí ojú ọ̀run.”
12 Ṣugbọn Ahasi dáhùn, ó ní: “Èmi kò ní bèèrè nǹkankan, n kò ní dán OLUWA wò.”
13 Aisaya bá dáhùn pé, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọmọ Dafidi, ṣé eniyan tí ẹ̀ ń yọ lẹ́nu kò to yín, Ọlọrun mi alára lókù tí ẹ tún ń yọ lẹ́nu?
14 Nítorí náà, OLUWA fúnrarẹ̀ yóo fun yín ní àmì kan. Ẹ gbọ́! Ọlọ́mọge kan yóo lóyún yóo sì bí ọmọkunrin kan, yóo pe orúkọ rẹ̀ ní Imanuẹli.
15 Nígbà tí yóo bá fi mọ bí a ti í kọ nǹkan burúkú, tí a sì í yan nǹkan rere, wàrà ati oyin ni àwọn eniyan yóo máa jẹ.
16 Nítorí pé kí ọmọ náà tó mọ bí a ti í kọ nǹkan burúkú tí a sì í yan nǹkan rere, ilẹ̀ àwọn ọba mejeeji tí wọn ń bà ọ́ lẹ́rù yìí yóo ti di ìkọ̀sílẹ̀.
17 “OLUWA yóo mú ọjọ́ burúkú dé bá ìwọ ati àwọn eniyan rẹ ati ilé baba rẹ, ọjọ́ tí kò ì tíì sí irú rẹ̀ rí, láti ìgbà tí Efuraimu ti ya kúrò lára Juda, OLUWA ń mú ọba Asiria bọ̀.
18 “Ní ọjọ́ náà OLUWA yóo súfèé pe àwọn eṣinṣin tí ó wà ní orísun gbogbo odò Ijipti ati àwọn oyin tí ó wà ní ilẹ̀ Asiria.
19 Gbogbo wọn yóo sì rọ́ wá sí ààrin àwọn àfonífojì, ati gbogbo kọ̀rọ̀ kọ̀rọ̀ ní ààrin àpáta, ati ara gbogbo igi ẹlẹ́gùn-ún ati gbogbo pápá.
20 “Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo mú ọba Asiria wá láti òdìkejì odò. Yóo lò ó bí abẹ ìfárí, yóo fi fá irun orí ati irun ẹsẹ̀ dànù, ati gbogbo irùngbọ̀n pàápàá.
21 “Ní ọjọ́ náà, eniyan yóo máa sin ẹyọ mààlúù kékeré kan ati aguntan meji péré,
22 wàrà tí yóo máa rí fún yóo pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé wàrà ati oyin ni yóo máa fi ṣe oúnjẹ jẹ. Nítorí pé wàrà ati oyin ni àwọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà yóo máa jẹ.
23 “Ní ọjọ́ náà, gbogbo ibi tí ẹgbẹrun ìtàkùn àjàrà wà, tí owó rẹ̀ tó ẹgbẹrun ṣekeli fadaka, yóo di igbó ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n agogo ati ẹ̀gún ọ̀gàn.
24 Àwọn eniyan yóo kó ọrun ati ọfà wá sibẹ, nítorí gbogbo ilẹ̀ náà yóo di igbó ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n agogo ati ẹ̀gún ọ̀gàn.
25 Gbogbo ara òkè tí wọn tí ń fi ọkọ́ ro tẹ́lẹ̀, ẹnikẹ́ni kò ní lè débẹ̀ mọ́, nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀wọ̀n agogo ati ẹ̀gún ọ̀gàn, gbogbo ibẹ̀ yóo wá di ibi tí mààlúù ati aguntan yóo ti máa jẹko.”
1 Lẹ́yìn náà, OLUWA sọ fún mi pé, “Mú ìwé kan tí ó fẹ̀, kí o kọ Maheriṣalali-haṣi-basi sí i lórí gàdàgbà gàdàgbà.”
2 Mo bá pe Alufaa Uraya ati Sakaraya, ọmọ Jebẹrẹkaya, kí wọn wá ṣe ẹlẹ́rìí mi nítorí wọ́n jẹ́ olóòótọ́.
3 Nígbà tí mo bá iyawo mi, tí òun náà jẹ́ wolii lò pọ̀, ó lóyún, ó sì bí ọmọkunrin. OLUWA bá sọ fún mi pé kí n sọ ọmọ náà ní Maheriṣalali-haṣi-basi.
4 Nítorí kí ọmọ náà tó mọ bí a tí ń pe ‘Baba mi’ tabi ‘Mama mi’, wọn óo ti kó àwọn nǹkan alumọni Damasku ati ìkógun Samaria lọ sí Asiria.
5 OLUWA tún bá mi sọ̀rọ̀ ó ní,
6 “Nítorí pé àwọn eniyan wọnyi kọ omi Ṣiloa tí ń ṣàn wẹ́rẹ́wẹ́rẹ́ sílẹ̀, wọ́n wá ń gbọ̀n jìnnìjìnnì níwájú Resini ati ọmọ Remalaya,
7 nítorí náà, ẹ wò ó, OLUWA yóo gbé ọba Asiria ati gbogbo ògo rẹ̀ dìde wá bá wọn, yóo sì bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí omi odò Yufurate, tí ó kún àkúnya, tí ó sì kọjá bèbè rẹ̀.
8 Yóo ya wọ Juda, yóo sì bò ó mọ́lẹ̀ bí ó ti ń ṣàn kọjá lọ, títí yóo fi mù ún dé ọrùn. Yóo ya wọ inú ilẹ̀ rẹ̀ látòkè délẹ̀; yóo sì bo gbogbo rẹ̀ mọ́lẹ̀. Kí Ọlọrun wà pẹlu wa.”
9 Ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, ẹ kó ara yín jọ! A óo fọ yín túútúú. Ẹ fetí sílẹ̀, gbogbo ẹ̀yin ará ilẹ̀ òkèèrè. Ẹ di ara yín ní àmùrè; a óo fọ yín túútúú. Ẹ di ara yín ní àmùrè, a óo fọ yín túútúú.
10 Bí ẹ gbìmọ̀ pọ̀ ìmọ̀ yín yóo di òfo. Ohun yòówù tí ẹ lè sọ, àpérò yín yóo di asán. Nítorí pé Ọlọrun wà pẹlu wa.
11 Nítorí ọwọ́ agbára ni OLUWA fi lé mi lára, nígbà tí ó ń sọ èyí fún mi. Ó sì ti kìlọ̀ fún mi pé kí n má bá àwọn eniyan wọnyi rìn, ó ní,
12 “Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ́wọ́ sí ọ̀tẹ̀ tí àwọn eniyan yìí ń dì. Bẹ́ẹ̀ ni o kò gbọdọ̀ bẹ̀rù ohun tí wọn ń bẹ̀rù.
13 OLUWA àwọn ọmọ ogun nìkan ni kí o kà sí mímọ́, òun ni kí ẹ̀rù rẹ̀ máa bà ọ́. Òun nìkan ni kí ọ̀rọ̀ rẹ̀ máa pá ọ láyà.
14 Yóo di ibi-mímọ́ ati òkúta ìdìgbòlù, ati àpáta tí ó ń mú kí eniyan kọsẹ̀, fún ilẹ̀ Israẹli mejeeji. Yóo di ẹ̀bìtì ati tàkúté fún àwọn ará Jerusalẹmu.
15 Ọ̀pọ̀ eniyan ni yóo kọsẹ̀ níbẹ̀; wọn yóo ṣubú, wọn yóo sì fọ́ wẹ́wẹ́. Tàkúté yóo mú wọn, ọwọ́ yóo sì tẹ̀ wọ́n.”
16 Di ẹ̀rí náà, fi èdìdì di ẹ̀kọ́ náà láàrin àwọn ọmọ ẹ̀yìn mi.
17 N óo dúró de OLUWA ẹni tí ó fojú pamọ́ fún ilé Jakọbu, n óo sì ní ìrètí ninu rẹ̀.
18 Ẹ wò ó! Èmi ati àwọn ọmọ tí OLUWA fún mi, a wà fún àmì ati ìyanu ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun, tí ń gbé orí òkè Sioni.
19 Nígbà tí wọ́n bá wí fun yín pé kí ẹ lọ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ àwọn àjẹ́ ati àwọn abókùúsọ̀rọ̀ tí wọn ń jẹ ẹnu wúyẹ́-wúyẹ́. Ṣé kò yẹ kí orílẹ̀-èdè wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Ọlọrun wọn? Ṣé lọ́dọ̀ òkú ni ó ti yẹ kí alààyè ti máa wádìí ọ̀rọ̀?
20 Ẹ lọ wádìí ninu ẹ̀kọ́ mímọ́ ati ẹ̀rí. Bí ẹnìkan bá sọ irú ọ̀rọ̀ yìí, kò sí òye ìmọ́lẹ̀ níbẹ̀.
21 Wọn yóo kọjá lọ lórí ilẹ̀ náà ninu ìnira ati ebi; nígbà tí ebi bá pa wọ́n, wọn yóo máa kanra, wọn óo gbé ojú wọn sókè, wọn óo sì gbé ọba ati Ọlọrun wọn ṣépè.
22 Wọn óo bojú wo ilẹ̀, kìkì ìdààmú ati òkùnkùn ati ìṣúdudu ati ìnira ni wọn óo rí. A óo sì sọ wọ́n sinu òkùnkùn biribiri.
1 Ṣugbọn kò ní sí ìṣúdudu fún ẹni tí ó wà ninu ìnira. Ní ìgbà àtijọ́, ó sọ ilẹ̀ Sebuluni ati ilẹ̀ Nafutali di yẹpẹrẹ, ṣugbọn nígbà ìkẹyìn yóo ṣe ilẹ̀ àwọn tí ó ń gbé apá ọ̀nà òkun lógo, títí lọ dé òdìkejì odò Jọdani, ati Galili níbi tí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè mìíràn ń gbé.
2 Àwọn tí ń rìn ninu òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá. Ìmọ́lẹ̀ sì ti tàn sí àwọn tí ń gbé ninu òkùnkùn biribiri.
3 Ó ti bukun orílẹ̀-èdè náà. Ó ti fi kún ayọ̀ wọn; wọ́n ń yọ̀ níwájú rẹ̀, bí ayọ̀ ìgbà ìkórè. Bí inú àwọn eniyan ti máa ń dùn nígbà tí wọ́n bá ń pín ìkógun.
4 Nítorí pé ó ti ṣẹ́ àjàgà tí ó wọ̀ wọ́n lọ́rùn, ati ọ̀pá tí wọn fí ń ru ẹrù sí èjìká, ati kùmọ̀ àwọn tí ń fìyà jẹ wọ́n. Ó ti ṣẹ́ wọn, bí ìgbà tí ó ṣẹ́ ti àwọn ará Midiani.
5 Gbogbo bàtà àwọn ológun, tí ń kilẹ̀ lójú ogun, ati gbogbo ẹ̀wù tí wọ́n ti yí mọ́lẹ̀ ninu ẹ̀jẹ̀ ni a óo dáná sun, iná yóo sì jó wọn run.
6 Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fún wa ní ọmọkunrin kan. Òun ni yóo jọba lórí wa. A óo máa pè é ní Ìyanu, Olùdámọ̀ràn, Ọlọrun alágbára, Baba ayérayé, Ọmọ-Aládé alaafia.
7 Ìjọba rẹ̀ yóo máa tóbi sí i, alaafia kò sì ní lópin ní ìjọba rẹ̀ lórí ìtẹ́ Dafidi. Yóo fìdí rẹ̀ múlẹ̀, yóo sì gbé e ró pẹlu ẹ̀tọ́ ati òdodo, láti ìgbà yìí lọ, títí ayérayé. Ìtara OLUWA àwọn ọmọ ogun ni yóo ṣe èyí
8 OLUWA ranṣẹ ìdájọ́ sí Jakọbu, àní, sórí àwọn ọmọ Israẹli.
9 Gbogbo eniyan ni yóo mọ̀, àwọn ará Efuraimu ati àwọn ará Samaria, àwọn tí wọn ń fọ́nnu pẹlu ìgbéraga pé:
10 Ṣé bíríkì ni wọ́n fi kọ́ àwọn ilé tí ó wó lulẹ̀? Òkúta gbígbẹ́ ni a óo fi tún wọn kọ́. Igi sikamore ni a fi kọ́ èyí tí wọ́n dà wó, ṣugbọn igi kedari dáradára ni a óo lò dípò wọn.
11 Nítorí náà OLUWA ti gbé ọ̀tá dìde sí wọn: Ó ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè sí wọn:
12 Àwọn ará Siria láti ìhà ìlà oòrùn, ati àwọn ará Filistia láti ìhà ìwọ̀ oòrùn; wọn óo gbé Israẹli mì. Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.
13 Sibẹsibẹ àwọn ọmọ Israẹli kò pada sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó jẹ wọ́n níyà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò wá OLUWA àwọn ọmọ-ogun.
14 Nítorí náà, OLUWA yóo fi ìyà jẹ Israẹli. Ní ọjọ́ kan ṣoṣo, yóo gé Israẹli lórí ati nírù.
15 Àwọn àgbààgbà ati àwọn ọlọ́lá wọn ni orí, àwọn wolii tí ń kọ́ àwọn eniyan ní ẹ̀kọ́ èké sì ni ìrù
16 Àwọn tí ń darí àwọn eniyan wọnyi ń ṣì wọ́n lọ́nà ni, àwọn tí wọn ń tọ́ sọ́nà sì ń já sinu ìparun.
17 Nítorí náà, OLUWA kò láyọ̀ lórí àwọn ọdọmọkunrin wọn, àánú àwọn aláìníbaba ati àwọn opó wọn kò sì ṣe é nítorí pé aṣebi ni gbogbo wọn, wọn kò sì mọ Ọlọrun, ọ̀rọ̀ burúkú ni wọ́n sì ń fi ẹnu wọn sọ. Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.
18 Ìwà burúkú wọn ń jó bí iná, tí ń jó ẹ̀gún wẹ́wẹ́ ati ẹ̀gún ọ̀gàn. Ó ń jó bíi igbó ńlá, ó sì ń yọ èéfín sókè lálá.
19 Nítorí ibinu OLUWA àwọn ọmọ ogun, ilẹ̀ náà jóná, àwọn eniyan ibẹ̀ dàbí èpò tí a dà sinu iná ẹnikẹ́ni kò sì dá ẹnìkejì rẹ̀ sí.
20 Wọ́n ń já nǹkan gbà lọ́tùn-ún, wọ́n ń jẹ ẹ́, sibẹ ebi ń pa wọ́n. Wọ́n ń jẹ àjẹrun lósì, sibẹ wọn kò yó, àwọn eniyan sì ń pa ara wọn jẹ.
21 Àwọn ará Manase ń bá àwọn ará Efuraimu jà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Efuraimu náà ń bá àwọn ará Manase jà. Àwọn mejeeji wá dojú ìjà kọ Juda. Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò dáwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.
1 Àwọn tí ń ṣe òfin tí kò tọ́ gbé! Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn akọ̀wé, tí ń kọ̀wé láti ni eniyan lára;
2 wọ́n ń dínà ìdájọ́ òdodo fún àwọn aláìní, wọn kò sì jẹ́ kí àwọn talaka ààrin àwọn eniyan mi rí ẹ̀tọ́ wọn gbà, kí wọ́n lè sọ àwọn opó di ìkógun.
3 Kí ni ẹ óo ṣe lọ́jọ́ ìjìyà yín tí ìparun bá dé láti òkèèrè? Ta ni ẹ óo sá tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ẹ óo kó ọrọ̀ yín sí?
4 Kò sí ohun tí ó kù àfi kí ẹ kú lójú ogun, tabi kí ẹ ká góńgó láàrin àwọn tí wọ́n kó lẹ́rú. Sibẹsibẹ inú OLUWA kò ní rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ní dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.
5 Háà! Asiria! Orílẹ̀-èdè tí mò ń lò bíi kùmọ̀, ati bíi ọ̀pá nígbà tí inú bá bí mi.
6 Mo rán wọn láti gbógun ti àwọn tí kò mọ Ọlọrun, ati àwọn eniyan tí wọ́n bá mú mi bínú. Pé kí wọ́n kó wọn lẹ́rù. Kí wọ́n kó wọn lẹ́rú kí wọ́n tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bíi ẹrọ̀fọ̀ tí à ń tẹ̀ mọ́lẹ̀ níta gbangba.
7 Ṣugbọn ọba Asiria kò pa irú ète yìí, kò sì ní irú èrò yìí lọ́kàn; gbogbo èrò ọkàn rẹ̀ ni láti pa ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè run
8 nítorí ó wí pé: “Ṣebí ọba ni gbogbo àwọn olórí ogun mi!
9 Ṣebí bíi Kakemiṣi ni Kalino rí, tí Hamati rí bíi Aripadi, tí Samaria kò sì yàtọ̀ sí Damasku?
10 Bí ọwọ́ mi ṣe tẹ àwọn ìlú àwọn abọ̀rìṣà, tí oriṣa wọn lágbára ju ti Jerusalẹmu ati Samaria lọ,
11 ṣé n kò ní lè ṣe sí Jerusalẹmu ati àwọn oriṣa rẹ̀ bí mo ti ṣe Samaria ati àwọn oriṣa rẹ̀?”
12 Nígbà tí OLUWA bá parí bírà tí ó ń dá ní òkè Sioni ati ní Jerusalẹmu, yóo fìyà jẹ ọba Asiria fún ìwà ìgbéraga ati àṣejù rẹ̀.
13 Nítorí ó ní, “Agbára mi ni mo fi ṣe èyí, ọgbọ́n mi ni mo fi ṣe é nítorí pé mo jẹ́ amòye. Mo yí ààlà àwọn orílẹ̀-èdè pada, mo kó ẹrù tí ó wà ninu ilé ìṣúra wọn. Mo ré àwọn tí wọ́n jókòó lórí ìtẹ́ bọ́ sílẹ̀ bí alágbára ọkunrin.
14 Mo nawọ́ kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, bí ẹni nawọ́ kó ọmọ ẹyẹ. Mo kó gbogbo ayé, bí ẹni kó ẹyin ẹyẹ tí ó kọ ẹyin rẹ̀ sílẹ̀, tí ó fò lọ, kò sí ẹnìkan tí ó lè ṣe nǹkankan, kò sí ẹnìkan tí ó lanu sọ̀rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò gbin.”
15 Ǹjẹ́ fáàrí àáké lè pọ̀ ju ti ẹni tí ó ń fi gégi lọ? Tabi ayùn lè fọ́nnu sí ẹni tí ó ń fi rẹ́ igi? Ǹjẹ́ kùmọ̀ lè mú ẹni tí ó ń lò ó lọ́wọ́, tabi kí ọ̀pá mú ẹni tí ó ni í lọ́wọ́?
16 Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo rán àìsàn apanirun sí ààrin àwọn akọni ọmọ ogun rẹ̀. Dípò ohun tí wọ́n fi ń ṣe ògo, ajónirun yóo jó wọn bí ìgbà tí iná bá jóni.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóo di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóo di ahọ́n iná; yóo sì jó àwọn ẹ̀gún wẹ́wẹ́ ati ẹ̀gún ọ̀gàn rẹ̀ run ní ọjọ́ kan.
18 OLUWA yóo pa àwọn igi ńlá inú igbó rẹ̀ run, yóo pa àwọn igi eléso ilẹ̀ rẹ́ tèsotèso, bí ìgbà tí àrùn bá gbẹ eniyan.
19 Ohun tí yóo kù ninu àwọn igi igbó rẹ̀ kò ní ju ohun tí ọmọde lè kà, kí ó sì kọ sílẹ̀ lọ.
20 Ní ọjọ́ náà, ìyókù Israẹli ati àwọn tí yóo yè ní agbo ilé Jakọbu, kò ní gbé ara lé ẹni tí ó ṣá wọn lọ́gbẹ́ mọ́, ṣugbọn OLUWA, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni wọn óo fẹ̀yìn tì ní òtítọ́.
21 Àwọn yòókù yóo pada, àwọn yòókù Jakọbu yóo pada sọ́dọ̀ Ọlọrun alágbára.
22 Israẹli, bí àwọn eniyan rẹ tilẹ̀ pọ̀ bí iyanrìn etí òkun, díẹ̀ ninu wọn ni yóo pada, nítorí ìparun ti di òfin ó sì kún fún òdodo
23 Nítorí OLUWA, OLUWA, àwọn ọmọ ogun yóo ṣe iṣẹ́ rẹ̀ ní àṣeparí láàrin gbogbo ayé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe é lófin.
24 Nítorí náà OLUWA, OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “Ẹ̀yin eniyan mi tí ń gbé Sioni, Ẹ má bẹ̀rù àwọn ará Asiria bí wọn bá fi ọ̀gọ lù yín, tabi tí wọn gbé ọ̀pá sókè si yín bí àwọn ará Ijipti ti ṣe si yín.
25 Nítorí pé láìpẹ́, ibinu mi si yín yóo kásẹ̀ nílẹ̀, n óo sì dojú ibinu mi kọ wọ́n láti pa wọ́n run.
26 Èmi, OLUWA àwọn ọmọ ogun, n óo fi ọ̀pá mi nà wọ́n, bí ìgbà tí mo na àwọn ará Midiani ní ibi àpáta Orebu. Ọ̀pá rẹ̀ yóo wà lórí òkun. Yóo tún gbé e sókè bí ó ti ṣe ní Ijipti.
27 Ní ọjọ́ náà, a óo gbé ẹrù tí ó dì lé ọ lórí kúrò, a óo sì fa àjàgà rẹ̀ dá kúrò lọ́rùn rẹ.”
28 Ó ti kúrò ní agbègbè Rimoni, ó ti dé sí Aiati; ó kọjá ní Migironi, ó kó ẹrù ogun rẹ̀ jọ sí Mikimaṣi.
29 Wọ́n sọdá sí òdìkejì odò wọ́n sùn ní Geba di ọjọ́ keji. Àwọn ará Rama ń wárìrì, àwọn ará Gibea, ìlú Saulu sá lọ.
30 Kígbe! Ìwọ ọmọbinrin Galimu. Fetí sílẹ̀ ìwọ Laiṣa, kí Anatoti sì dá a lóhùn.
31 Madimena ń sá lọ, àwọn ará Gebimu ń sá àsálà.
32 Ní òní olónìí, yóo dúró ní Nobu, yóo di ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn òkè Sioni, àní òkè Jerusalẹmu.
33 Ẹ wò ó! OLUWA, OLUWA àwọn ọmọ ogun, yóo gé àwọn ẹ̀ka igi náà pẹlu agbára tí ó bani lẹ́rù. Yóo gé àwọn tí ó ga fíofío lulẹ̀, yóo sì rẹ àwọn agbéraga sílẹ̀.
34 Yóo fi àáké gé àwọn igi igbó tí ó dí, Lẹbanoni pẹlu gbogbo igi ńláńlá rẹ̀ yóo sì wó.
1 Èèhù kan yóo sọ jáde láti inú kùkùté igi Jese, ẹ̀ka kan yóo sì yọ jáde láti inú àwọn gbòǹgbò rẹ̀.
2 Ẹ̀mí OLUWA yóo bà lé e, ẹ̀mí ọgbọ́n ati òye, ẹ̀mí ìmọ̀ràn ati agbára, ẹ̀mí ìmọ̀ ati ìbẹ̀rù OLUWA.
3 Ìbẹ̀rù OLUWA ni yóo jẹ́ ìdùnnú rẹ̀ kì í ṣe ohun tí ó fojú rí, tabi èyí tí ó fi etí gbọ́ ni yóo fi ṣe ìdájọ́.
4 Ṣugbọn yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ àwọn talaka, yóo fi ẹ̀tọ́ gbèjà àwọn onírẹ̀lẹ̀, yóo fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ na ayé bíi pàṣán, yóo sì fi èémí ẹnu rẹ̀ pa àwọn oníṣẹ́ ibi.
5 Òdodo ni yóo fi ṣe àmùrè ìgbàdí rẹ̀, yóo sì fi òtítọ́ ṣe àmùrè ìgbànú rẹ̀.
6 Ìkookò yóo máa bá ọ̀dọ́ aguntan gbé, àmọ̀tẹ́kùn yóo sùn sílẹ̀ pẹlu ọmọ ewúrẹ́, ọmọ mààlúù, ati kinniun, ati ẹgbọ̀rọ̀ ẹran àbọ́pa yóo jọ máa gbé pọ̀, ọmọ kékeré yóo sì máa kó wọn jẹ.
7 Mààlúù ati ẹranko beari yóo jọ máa jẹun pọ̀, àwọn ọmọ wọn yóo jọ máa sùn pọ̀, kinniun yóo sì máa jẹ koríko bí akọ mààlúù.
8 Ọmọ ọmú yóo máa ṣeré lórí ihò paramọ́lẹ̀, ọmọ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ já lẹ́nu ọmú yóo máa fi ọwọ́ bọ inú ihò ejò.
9 Wọn kò ní ṣe eniyan ní jamba mọ́, tabi kí wọ́n bu eniyan jẹ ní gbogbo orí òkè mímọ́ mi. Nítorí ìmọ̀ OLUWA yóo kún gbogbo ayé bí omi ṣe kún gbogbo inú òkun.
10 Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jese yóo dúró bí àsíá fún àwọn orílẹ̀-èdè, òun ni àwọn orílẹ̀-èdè yóo máa wá. Ibùgbé rẹ̀ yóo jẹ́ èyí tí ó lógo.
11 Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo na ọwọ́ rẹ̀ lẹẹkeji, yóo ra àwọn eniyan rẹ̀ yòókù pada ní oko ẹrú, láti Asiria, ati Ijipti, láti Patosi ati Etiopia, láti Elamu ati Ṣinari, láti Amati ati àwọn erékùṣù òkun.
12 Yóo gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè, yóo kó àwọn Israẹli tí a ti patì jọ. Yóo ṣa àwọn ọmọ Juda tí wọ́n fọ́nká jọ, láti orígun mẹrẹẹrin ilẹ̀ ayé.
13 Owú jíjẹ Efuraimu yóo kúrò, a óo sì pa àwọn tí ń ni Juda lára run. Efuraimu kò gbọdọ̀ jowú Juda mọ́, bẹ́ẹ̀ ni Juda kò gbọdọ̀ ni Efuraimu lára mọ.
14 Wọn óo kọlu àwọn ará Filistini ní ìhà ìwọ̀ oòrùn, wọn yóo jọ ṣẹgun àwọn ará ìlà oòrùn. Wọn yóo sì jọ dojú ìjà kọ Edomu ati Moabu. Àwọn ará Amoni yóo gbọ́ràn sí wọn lẹ́nu.
15 OLUWA yóo pa Ijipti run patapata. Yóo na ọwọ́ ìjì líle sí orí odò Pirati, yóo sì pín in sí ọ̀nà meje, kí àwọn eniyan lè máa ríbi là á kọjá.
16 Ọ̀nà tí ó gbòòrò yóo wà láti Asiria, fún ìyókù àwọn eniyan rẹ̀; bí ó ti ṣe wà fún àwọn ọmọ Israẹli, nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ijipti.
1 O óo sọ ní ọjọ́ náà pé, “N óo fi ọpẹ́ fún OLUWA, nítorí pé bí ó tilẹ̀ bínú sí mi, inú rẹ̀ ti rọ̀, ó sì tù mí ninu.
2 Wò ó! Ọlọrun ni olùgbàlà mi, n óo gbẹ́kẹ̀lé e ẹ̀rù kò sì ní bà mí, nítorí pé OLUWA Ọlọrun ni agbára mi, ati orin mi, òun sì ni Olùgbàlà mi.”
3 Tayọ̀tayọ̀ ni ẹ óo fi máa rí ìgbàlà bí ẹni pọn omi láti inú kànga.
4 Ẹ óo sọ ní ọjọ́ náà pé, “Ẹ fọpẹ́ fún OLUWA, ẹ ké pe orúkọ rẹ̀, ẹ kéde iṣẹ́ rere rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè; ẹ kéde pé a gbé orúkọ rẹ̀ ga.
5 Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA nítorí ó ṣe nǹkan tí ó lógo, jẹ́ kí èyí di mímọ̀ ní gbogbo ayé.
6 Ẹ̀yin tí ń gbé Sioni, ẹ hó, ẹ kọrin ayọ̀, ẹ̀yin olùgbé Sioni, nítorí Ẹni ńlá ni Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó wà láàrin yín.”
1 Ìran tí Aisaya ọmọ Amosi rí sí Babiloni:
2 Ẹ ta àsíá ní orí òkè gíga, ẹ gbóhùn sókè sí wọn. Ẹ juwọ́, kí àwọn ológun gba ẹnu ibodè àwọn ọlọ́lá wọlé.
3 Èmi pàápàá ti pàṣẹ fún àwọn tí mo yà sọ́tọ̀, mo ti pe àwọn akọni mi, tí mo fi ń yangàn, láti fi ibinu mi hàn.
4 Gbọ́ ariwo lórí òkè, bí ohùn ọ̀pọ̀ eniyan, gbọ́ ariwo ìdàrúdàpọ̀ ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ń péjọ pọ̀! OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ń kó àwọn ọmọ ogun jọ fún ogun.
5 Wọ́n wá láti ilẹ̀ òkèèrè, láti ìpẹ̀kun ayé. OLUWA ń bọ̀ pẹlu àwọn ohun ìjà ibinu rẹ̀, tí yóo fi pa gbogbo ayé run.
6 Ẹ pohùnréré ẹkún, nítorí pé ọjọ́ OLUWA súnmọ́lé, yóo dé bí ìparun láti ọwọ́ Olodumare.
7 Nítorí náà ọwọ́ gbogbo eniyan yóo rọ, ọkàn gbogbo eniyan yóo rẹ̀wẹ̀sì;
8 ẹnu yóo sì yà wọ́n. Ìpayà ati ìrora yóo mú wọn, wọn yóo wà ninu ìrora bí obinrin tí ó ń rọbí; wọn óo wo ara wọn tìyanu-tìyanu, ojú yóo sì tì wọ́n.
9 Wò ó! Ọjọ́ OLUWA dé tán, tìkàtìkà pẹlu ìrúnú ati ibinu gbígbóná láti sọ ayé di ahoro, ati láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
10 Nítorí àgbájọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóo kọ̀, wọn kò ní tan ìmọ́lẹ̀. Oòrùn yóo ṣókùnkùn nígbà tí ó bá yọ, òṣùpá kò sì ní tan ìmọ́lẹ̀.
11 N óo fìyà jẹ ayé nítorí iṣẹ́ ibi rẹ̀, n óo sì jẹ àwọn ìkà níyà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. N óo fòpin sí àṣejù àwọn onigbeeraga, n óo rẹ ìgbéraga àwọn tí kò lójú àánú sílẹ̀.
12 N óo sọ eniyan di ohun tí ó ṣọ̀wọ́n ju wúrà dáradára lọ, irú eniyan yóo ṣọ̀wọ́n ju wúrà ilẹ̀ Ofiri lọ.
13 Nítorí náà n óo mú kí àwọn ọ̀run wárìrì ayé yóo sì mì tìtì tóbẹ́ẹ̀ tí yóo sún kúrò ní ipò rẹ̀, nítorí ibinu OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ọjọ́ tí inú rẹ̀ bá ru.
14 Eniyan yóo dàbí àgbọ̀nrín tí ọdẹ ń lé, ati bí aguntan tí kò ní olùṣọ́; olukuluku yóo doríkọ ọ̀dọ̀ àwọn eniyan rẹ̀, wọn óo sì sá lọ sí ilẹ̀ wọn.
15 Ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá rí, wọn óo fi ọ̀kọ̀ gún un pa, ẹni tí ọwọ́ bá tẹ̀, idà ni wọ́n ó fi pa á.
16 A óo so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ lójú wọn, a óo kó ilé wọn, a óo sì bá àwọn obinrin wọn lòpọ̀ pẹlu agbára.
17 Wò ó! N óo rú àwọn ará Media sókè sí wọn, àwọn tí wọn kò bìkítà fún fadaka bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ka wúrà sí. Wọn óo wá bá Babiloni jà.
18 Wọn yóo fi ọfà pa àwọn ọdọmọkunrin, wọn kò ní ṣàánú oyún inú, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣàánú àwọn ọmọde.
19 Babiloni, ìwọ tí o lógo jù láàrin gbogbo ìjọba ayé, ìwọ tí o jẹ́ ẹwà ati ògo àwọn ará Kalidea, yóo dàbí Sodomu ati Gomora, nígbà tí Ọlọrun pa wọ́n run.
20 Ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀ láti ìran dé ìran, àwọn ará Arabia kankan kò ní pa àgọ́ sibẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn darandaran kankan kò ní jẹ́ kí agbo aguntan wọn sinmi níbẹ̀.
21 Ṣugbọn àwọn ẹranko ní yóo máa sùn níbẹ̀ ilé rẹ̀ yóo sì kún fún ẹyẹ òwìwí, ògòǹgò yóo máa gbè ibẹ̀ ẹhànnà òbúkọ yóo sì máa ta pọ́núnpọ́nún káàkiri ibẹ̀.
22 Àwọn ìkookò yóo máa ké ninu ilé ìṣọ́ rẹ̀, ààfin rẹ̀ yóo di ibùgbé àwọn ajáko, àkókò rẹ̀ súnmọ́ etílé, ọjọ́ rẹ̀ kò sì ní pẹ́ mọ́.
1 OLUWA yóo ṣíjú àánú wo Jakọbu yóo tún yan Israẹli, yóo sì fi wọ́n sórí ilẹ̀ wọn. Àwọn àlejò yóo darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóo sì di ọ̀kan náà pẹlu ilé Jakọbu.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóo ràn wọ́n lọ́wọ́ láti pada sí ilẹ̀ wọn, àwọn orílẹ̀-èdè wọnyi yóo sì di ẹrú fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọn yóo pada sọ àwọn tí ó kó wọn lẹ́rú di ẹrú, wọn yóo sì jọba lórí àwọn tí ó ni wọ́n lára.
3 Nígbà tí OLUWA bá fun yín ní ìsinmi kúrò ninu làálàá ati rògbòdìyàn ati iṣẹ́ àṣekára tí wọn ń fi tipá mu yín ṣe,
4 ẹ óo kọrin òwe bú ọba Babiloni pé: “Agbára aninilára ti pin ìpayà ojoojumọ ti dópin.
5 OLUWA ti ṣẹ́ ọ̀pá àṣẹ àwọn ẹni ibi, ati ọ̀pá àṣẹ àwọn olórí
6 tí wọn ń fi ibinu lu àwọn eniyan láì dáwọ́ dúró, tí wọn ń fi ibinu ṣe àkóso àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ń ṣe inúnibíni lemọ́lemọ́.
7 Gbogbo ayé wà ní ìsinmi ati alaafia wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin ayọ̀.
8 Àwọn igi Sipirẹsi ń yọ̀ yín; àwọn igi Kedari ti Lẹbanoni sì ń sọ pé, ‘Láti ìgbà tí a ti rẹ ọba Babiloni sílẹ̀, kò sí agégi kan tí ó wá dààmú wa mọ́.’
9 “Isà òkú ti lanu sílẹ̀ láti pàdé rẹ bí o bá ti ń dé. Ó ta àwọn òkú ọ̀run jí láti kí ọ, àwọn tí wọ́n ṣe pataki ní àkókò wọn, Ó gbé gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè dìde lórí ìtẹ́ wọn.
10 Gbogbo wọn yóo wí fún ọ pé, ‘Àárẹ̀ ti mu yín gẹ́gẹ́ bí ó ti mú àwa náà. Ẹ ti dàbí i wa.
11 A ti fa ògo yín ati ohùn hapu yín sinu isà òkú. Ìdin di ibùsùn tí ẹ sùn lé lórí àwọn kòkòrò ni ẹ sì fi bora bí aṣọ.’
12 “Ọba Babiloni, wò ó! Bí o ti jábọ́ láti ojú ọ̀run, ìwọ tí o dàbí ìràwọ̀ òwúrọ̀! Wò ó bí a ti sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀, ìwọ tí o ti pa ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè run rí.
13 Ó pinnu lọ́kàn ara rẹ̀ pé, ‘N óo gòkè dé ọ̀run, n óo gbé ìtẹ́ mi kọjá àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run; n óo jókòó lórí òkè àpéjọ àwọn eniyan, ní ìhà àríwá ní ọ̀nà jíjìn réré.
14 N óo gòkè kọjá ìkùukùu ojú ọ̀run, n óo wá dàbí Olodumare.’
15 Ṣugbọn a já ọ lulẹ̀ sinu isà òkú, sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.
16 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá rí ọ yóo tẹjú mọ́ ọ, wọ́n óo fi ọ́ ṣe àríkọ́gbọ́n pé, ‘Ṣé ọkunrin tí ó ń kó ìpayà bá gbogbo ayé nìyí, tí ó ń mi àwọn orílẹ̀-èdè jìgìjìgì;
17 ẹni tí ó sọ ayé di aṣálẹ̀, tí ó sì pa àwọn ìlú ńláńlá rẹ̀ run, ẹni tí kì í dá àwọn tí ó bá wà ní ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀?’
18 Gbogbo ọba àwọn orílẹ̀-èdè dùbúlẹ̀ ninu ògo wọn olukuluku ninu ibojì tirẹ̀.
19 Ṣugbọn a lé ìwọ kúrò ninu ibojì rẹ, bí ọmọ tí a bí kí oṣù rẹ̀ tó pé, tí a gbé òkú rẹ̀ sọnù; tí a jù sáàrin òkú àwọn jagunjagun tí a pa lójú ogun; àwọn tí a jù sinu kòtò olókùúta, bí àwọn tí a tẹ̀ ní àtẹ̀pa.
20 A kò ní sin ọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba yòókù, nítorí pé o ti pa ilẹ̀ rẹ run, o sì ti pa àwọn eniyan rẹ. Kí á má dárúkọ àwọn ìran ẹni ibi mọ́ títí lae!
21 Ẹ múra láti pa àwọn ọmọ rẹ̀ run nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wọn, kí wọn má baà tún gbógun dìde, kí wọn gba gbogbo ayé kan, kí wọn sì kọ́ ọpọlọpọ ìlú sórí ilẹ̀ ayé.”
22 OLUWA àwọn ọmọ ogun ní, “N óo gbógun tì wọ́n, n óo pa orúkọ Babiloni rẹ́ ati ìyókù àwọn eniyan tí ó wà ninu rẹ̀, ati arọmọdọmọ wọn.
23 N óo sọ ọ́ di ibùgbé òòrẹ̀, adágún omi yóo wà káàkiri inú rẹ, n óo sì fi ọwọ̀ ìparun gbá a. Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
24 OLUWA àwọn ọmọ ogun ti búra, ó ní, “Bí mo ti rò ó bẹ́ẹ̀ ni yóo rí; ohun tí mo pinnu ni yóo sì ṣẹ.
25 Pé n óo pa àwọn ará Asiria run lórí ilẹ̀ mi; n óo sì fẹsẹ̀ tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lórí àwọn òkè mi. Àjàgà rẹ̀ yóo bọ́ kúrò lọ́rùn àwọn eniyan mi, ati ẹrù tí ó dì lé wọn lórí.
26 Ohun tí mo ti pinnu nípa gbogbo ayé nìyí, mo sì ti na ọwọ́ mi sórí orílẹ̀-èdè gbogbo láti jẹ wọ́n níyà.”
27 OLUWA àwọn ọmọ ogun ti pinnu; ta ni ó lè yí ìpinnu rẹ̀ pada? Ó ti dáwọ́lé ohun tí ó fẹ́ ṣe ta ni lè ká a lọ́wọ́ kò?
28 Ọ̀rọ̀ OLUWA tí Aisaya sọ ní ọdún tí ọba Ahasi kú:
29 Gbogbo ẹ̀yin ará Filistini, ẹ má yọ̀ pé a ti ṣẹ́ ọ̀pá tí ó lù yín; nítorí pé paramọ́lẹ̀ ni yóo yọ jáde láti inú àgékù ejò, ejò tí ń fò sì ni ọmọ rẹ̀ yóo yà.
30 Àkọ́bí talaka yóo rí oúnjẹ jẹ, aláìní yóo sì dùbúlẹ̀ láì léwu. Ṣugbọn n óo fi ìyàn pa àwọn ọmọ ilẹ̀ rẹ, a óo sì fi idà pa àwọn tó kù ní ilẹ̀ rẹ.
31 Máa sọkún, ìwọ ẹnubodè, kí ìwọ ìlú sì figbe ta. Ẹ̀yin ará Filistini, ẹ máa gbọ̀n jìnnìjìnnì nítorí pé àwọn ọmọ ogun kan ń rọ́ bọ̀ bí èéfín, láti ìhà àríwá, kò sí ọ̀kan ninu àwọn ọmọ ogun wọn tí ó ń ṣe dìẹ̀dìẹ̀ bọ̀ lẹ́yìn.
32 Èsì wo ni a óo fún àwọn ikọ̀ orílẹ̀-èdè Filistini? A óo sọ fún wọn pé, “OLUWA ti fi ìdí Sioni sọlẹ̀ àwọn tí à ń pọ́n lójú láàrin àwọn eniyan rẹ̀ yóo fi ibẹ̀ ṣe ibi ààbò.”
1 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA sọ nípa ilẹ̀ Moabu nìyí: Nítorí tí a wó ìlú Ari ati Kiri lulẹ̀ ní òru ọjọ́ kan ṣoṣo, ó parí fún Moabu.
2 Àwọn ọmọbinrin Diboni ti gun àwọn ibi pẹpẹ tí wọ́n ti ń bọ̀rìṣà lọ, wọ́n lọ sọkún. Moabu ń pohùnréré ẹkún nítorí Nebo ati Medeba. Gbogbo orí wọn pá, wọ́n sì ti fá gbogbo irùngbọ̀n wọn.
3 Wọ́n da aṣọ ọ̀fọ̀ bora ní ìta gbangba. Gbogbo wọn dúró lórí òrùlé ilé wọn, ati ní gbogbo gbàgede, wọ́n ń pohùnréré ẹkún, omijé sì ń dà lójú wọn.
4 Heṣiboni ati Eleale ń kígbe lóhùn rara, àwọn ará Jahasi gbọ́ ariwo wọn; nítorí náà àwọn ọmọ ogun Moabu sọkún, ọkàn rẹ̀ sì wárìrì.
5 Ọkàn mi sọkún fún Moabu; àwọn ìsáǹsá rẹ̀ sá lọ sí Soari ati Egilati Ṣeliṣiya. Ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Luhiti, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ, wọ́n sì ń kígbe arò bí wọ́n tí ń lọ sí Horonaimu.
6 Àwọn odò Nimrimu di aṣálẹ̀, koríko ibẹ̀ gbẹ; àwọn ohun ọ̀gbìn tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń yọ jóná mọ́lẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ewé kò rú mọ́.
7 Nítorí náà àwọn ohun tí wọ́n ní lọpọlọpọ ati ohun ìní tí wọn ti kó jọ, ni wọ́n kó lọ sí ìkọjá odò Wilo.
8 Nítorí ariwo kan ti gba gbogbo ilẹ̀ Moabu kan, ẹkún náà dé Egilaimu, ìpohùnréré náà sì dé Beerelimu.
9 Nítorí odò Diboni kún fún ẹ̀jẹ̀, sibẹsibẹ n óo jẹ́ kí ohun tí ó jù bẹ́ẹ̀ lọ dé bá a. Kinniun ni yóo pa àwọn ará Moabu tí ó bá ń sá lọ ati àwọn eniyan tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà.
1 Wọ́n ti kó àgbò láti Sela, ní ọ̀nà aṣálẹ̀, wọ́n fi ranṣẹ sí aláṣẹ ilẹ̀ náà, ní òkè Sioni.
2 Àwọn ọmọbinrin Moabu dúró létí odò Anoni, wọ́n ń rìn síwá, sẹ́yìn, wọ́n ń lọ sókè, sódò, bí ọmọ ẹyẹ tí a lé kúrò ninu ìtẹ́.
3 “Gbà wá ní ìmọ̀ràn, máa ṣe ẹ̀tọ́ fún wa. Fi òjìji rẹ dáàbò bò wá, kí ara lè tù wá lọ́sàn-án gangan, bí ẹni pé alẹ́ ni. Dáàbò bo àwọn tí a lé jáde; má tú àṣírí ẹni tí ń sálọ.
4 Jẹ́ kí àwọn tí a lé jáde ní Moabu, máa gbé ààrin yín. Dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn apanirun.” Nígbà tí aninilára kò bá sí mọ́ tí ìparun bá dópin, tí atẹnimọ́lẹ̀ bá ti kúrò ní ilẹ̀ náà.
5 Nígbà náà a óo fìdí ìtẹ́ múlẹ̀ pẹlu ìfẹ́ tí kì í yẹ̀. Ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ati òdodo yóo jókòó lórí ìtẹ́ náà, Yóo dúró lórí òtítọ́ ní ìdílé Dafidi.
6 A ti gbọ́ ìròyìn ìgbéraga Moabu, bí ó ṣe ń ṣe àfojúdi tí ó sì ń sọ ìsọkúsọ: ṣugbọn lásán ni ìgbéraga rẹ̀.
7 Nítorí náà, kí Moabu máa pohùnréré ẹkún, kí gbogbo eniyan máa sun ẹkún arò ní Moabu. Wọn óo sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, nígbà tí wọn ba ranti àkàrà Kiri Heresi, tí ó ní èso àjàrà ninu.
8 Gbogbo oko ni ó rọ ní Heṣiboni; bẹ́ẹ̀ náà ni ọgbà Sibuma: àwọn olórí orílẹ̀-èdè ti gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lulẹ̀, èyí tí ó tàn kálẹ̀ dé Jaseri títí dé inú aṣálẹ̀. Ìtàkùn rẹ̀ tàn kálẹ̀, wọ́n kọjá sí òdìkejì òkun.
9 Nítorí náà mo sọkún fún ọgbà àjàrà Sibuma bí mo ṣe sọkún fún Jaseri; mo sì sọkún nítorí Heṣiboni ati Eleale, mo sọkún, omi ń dà lójú mi pòròpòrò nítorí gbogbo ìkórè yín, ati èso oko yín ni ogun ti kó lọ.
10 Wọ́n ti kó ayọ̀ ati ìdùnnú lọ kúrò ninu oko eléso; ẹnikẹ́ni kò kọrin bẹ́ẹ̀ ni kò sí ariwo híhó ninu ọgbà àjàrà wọn. Kò sí àwọn tí ó ń pọn ọtí ninu rẹ̀ mọ́ bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ariwo àwọn tí ń pọn ọtí mọ́.
11 Nítorí náà, ẹ̀mí mi kọrin arò bíi ti dùùrù fún Moabu, ọkàn mi kérora, fún Moabu ati Kiri Heresi.
12 Nígbà tí Moabu bá wá siwaju, tí ó fi gbogbo agbára gbadura ninu ilé oriṣa rẹ̀, títí ó fi rẹ̀ ẹ́, adura rẹ̀ kò ní gbà.
13 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA ti kọ́ sọ nípa Moabu tẹ́lẹ̀ nìyí.
14 Ṣugbọn nisinsinyii, OLUWA ní, “Nígbà tí a óo fi rí ọdún mẹta, tíí ṣe iye ọdún alágbàṣe, a óo ti sọ ògo Moabu di ilẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé eniyan inú rẹ̀ pọ̀, àwọn díẹ̀ ni yóo ṣẹ́kù, àárẹ̀ yóo sì ti mú wọn.”
1 Ọ̀rọ̀ OLUWA sí ilẹ̀ Damasku nìyí: “Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́ òkítì àlàpà ni yóo dà.
2 Àwọn ìlú rẹ̀ yóo di àkọ̀tì títí lae wọn yóo di ibùjẹ àwọn ẹran, níbi tí àwọn ẹran yóo dùbúlẹ̀, tí ẹnikẹ́ni kò sì ní dẹ́rùbà wọ́n.
3 Ìlú olódi kò ní sí mọ́ ní Efuraimu, kò sì ní sí ìjọba mọ́ ní Damasku, àwọn tí wọ́n bá ṣẹ́kù ní Siria yóo sì dàbí ògo àwọn ọmọ Israẹli, OLUWA àwọn ọmọ ogun ló sọ bẹ́ẹ̀.
4 “Tó bá di ìgbà náà, a óo rẹ ògo àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀, ọrọ̀ wọn yóo di àìní.
5 Yóo dàbí ìgbà tí eniyan kórè ọkà lóko, tí ó kó ṣiiri ọkà kún apá. Tí àwọn kan tún wá ṣa ọkà yòókù, tí àwọn tí wọn kọ́ kórè ọkà gbàgbé ní àfonífojì Refaimu.
6 Àṣàkù yóo kù níbẹ̀, bí ìgbà tí eniyan gbọn igi olifi, yóo ku meji tabi mẹta péré ní góńgó orí igi, tabi bíi mẹrin tabi marun-un lórí ẹ̀ka igi.” OLUWA Ọlọrun Israẹli ló sọ bẹ́ẹ̀.
7 Tó bá di ìgbà náà, àwọn eniyan yóo bọ̀wọ̀ fún Ẹlẹ́dàá wọn, wọn yóo sì máa wo ojú Ẹni Mímọ́ Israẹli.
8 Wọn kò ní náání pẹpẹ tí wọ́n fọwọ́ ara wọn tẹ́ bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní gbójúlé àwọn ère tí wọ́n fọwọ́ ara wọn ṣe, ìbáà jẹ́ oriṣa Aṣera tabi pẹpẹ turari.
9 Tó bá di ìgbà náà, àwọn ìlú olódi ńláńlá wọn yóo dàbí àwọn ìlú tí àwọn ará Hifi ati àwọn ará Amori sá kúrò níbẹ̀, nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbógun tì wọ́n; gbogbo rẹ̀ yóo di ahoro.
10 Nítorí pé ẹ ti gbàgbé Ọlọrun olùgbàlà yín, ẹ kò ranti Àpáta tí ó jẹ́ ààbò yín. Nítorí náà bí ẹ tilẹ̀ gbin igi dáradára tí ẹ̀ ń bọ ọ́, tí ẹ sì gbin òdòdó àjèjì tí ẹ̀ ń sìn ín;
11 wọn ìbáà hù lọ́jọ́ tí ẹ gbìn wọ́n, kí wọ́n yọ òdòdó ní òwúrọ̀ ọjọ́ tí ẹ lọ́ wọn sibẹsibẹ kò ní sí ìkórè ní ọjọ́ ìbànújẹ́ ati ìrora tí kò lóògùn.
12 Ẹ gbọ́ ariwo ọ̀pọ̀ eniyan, wọ́n ń hó bí ìgbì òkun. Ẹ gbọ́ ìró àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n ń hó bíi ríru omi òkun ńlá.
13 Ìró àwọn orílẹ̀-èdè dàbí ti omi òkun ńlá ṣugbọn OLUWA yóo bá wọn wí wọn óo sì sá lọ. Wọn óo dàbí ìràwé tí afẹ́fẹ́ ń gbé lọ lórí òkè, ati bí eruku tí ìjì líle ń fẹ́ kiri.
14 Ìdágìrì yóo bá wọn ní ìrọ̀lẹ́, kí ilẹ̀ tó mọ́ wọn kò ní sí mọ́; bẹ́ẹ̀ ni yóo rí fún àwọn tí wọ́n fogun kó wa, bẹ́ẹ̀ ni yóo rí fún àwọn tí wọ́n kó wa lẹ́rù lọ.
1 Ó ṣe, ní òkè àwọn odò kan ní ilẹ̀ Sudani ibìkan wà tí àwọn ẹyẹ ti ń fò pẹ̀ẹ̀rẹ̀pẹ̀.
2 Ẹni tí ó rán ikọ̀ lọ sí òkè odò Naili, tí wọ́n fẹní ṣọkọ̀ ojú omi. Ẹ lọ kíá, ẹ̀yin iranṣẹ ayára-bí-àṣá, ẹ lọ sọ́dọ̀ orílẹ̀-èdè tí ó lágbára, tí ara wọn ń dán, àwọn tí àwọn eniyan tí wọ́n súnmọ́ wọn ati àwọn tí ó jìnnà sí wọn ń bẹ̀rù. Orílẹ̀-èdè tí ó lágbára, tíí sìí máa ń ṣẹgun ọ̀tá, àwọn tí odò la ilẹ̀ wọn kọjá.
3 Gbogbo aráyé, ẹ̀yin tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé, nígbà tí a bá gbé àsíá sókè lórí àwọn òkè, ẹ wò ó, nígbà tí a bá fun fèrè ogun, ẹ gbọ́.
4 Nítorí pé OLUWA sọ fún mi pé òun óo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wolẹ̀ láti ibi ibùgbé òun bí ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán gangan, ati bí ìkùukùu ninu ooru ìgbà ìkórè.
5 Nítorí pé kí ó tó di ìgbà ìkórè, lẹ́yìn tí ìtànná àjàrà bá ti rẹ̀, tí ó di èso, tí àjàrà bẹ̀rẹ̀ sí gbó, tí ó ń pọ́n bọ̀, ọ̀tá yóo ti dòjé bọ àwọn ìtàkùn àjàrà, yóo sì gé gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ kúrò.
6 Gbogbo wọn yóo wà nílẹ̀, wọn yóo di ìjẹ fún àwọn ẹyẹ orí òkè, ati àwọn ẹranko inú ìgbẹ́. Àwọn ẹyẹ yóo fi wọ́n ṣe oúnjẹ ní ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn, àwọn ẹranko yóo fi wọ́n ṣe oúnjẹ jẹ ní ìgbà òtútù.
7 Ní àkókò náà, àwọn eniyan tí wọ́n ga, tí wọ́n sì ń dán, tí àwọn tí wọ́n súnmọ́ wọn, ati àwọn tí wọ́n jìnnà sí wọn ń bẹ̀rù, orílẹ̀-èdè tí ó lágbára, tíí sì í máa ń ṣẹgun ọ̀tá, tí odò la ilẹ̀ wọn kọjá, wọn óo mú ẹ̀bùn wá fún OLUWA àwọn ọmọ ogun, ní orí òkè Sioni, tí àwọn eniyan ń jọ́sìn ní orúkọ OLUWA àwọn ọmọ ogun.
1 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Ijipti nìyí: OLUWA gun ìkùukùu lẹ́ṣin, ó ń yára bọ̀ wá sí Ijipti. Àwọn oriṣa Ijipti yóo máa gbọ̀n níwájú rẹ̀, ọkàn àwọn ará Ijipti yóo sì dàrú.
2 N óo dá ìdàrúdàpọ̀ sílẹ̀ láàrin àwọn ará Ijipti, olukuluku yóo máa bá arakunrin rẹ̀ jà, àwọn aládùúgbò yóo máa bá ara wọn jà, ìlú kan yóo gbógun ti ìlú keji, ìjọba yóo máa dìde sí ara wọn.
3 Ìrẹ̀wẹ̀sì yóo dé bá àwọn ará Ijipti, n óo sọ ète wọn di òfo. Wọn yóo lọ máa wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ àwọn oriṣa ati àwọn aláfọ̀ṣẹ ati lọ́dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀, ati àwọn oṣó.
4 Ṣugbọn n óo fi Ijipti lé aláìláàánú akóniṣiṣẹ́ kan lọ́wọ́ ìkà kan ni yóo sì jọba lé wọn lórí, bẹ́ẹ̀ ni Oluwa, OLUWA àwọn ọmọ ogun wí.
5 Omi odò Naili yóo gbẹ, yóo gbẹ, àgbẹkanlẹ̀.
6 Gbogbo odò wọn yóo máa rùn, gbogbo àwọn odò tí ó ṣàn wọ odò Naili ní Ijipti, ni yóo fà, tí yóo sì gbẹ: Gbogbo koríko odò yóo rà.
7 Etí odò Naili yóo di aṣálẹ̀, gbogbo ohun tí wọ́n bá gbìn sibẹ yóo gbẹ, ẹ̀fúùfù óo sì gbá wọn dànù.
8 Àwọn apẹja tí ń fi ìwọ̀ ninu odò Naili yóo ṣọ̀fọ̀, wọn óo sì sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn; àwọn tí ń fi àwọ̀n pẹja yóo kérora.
9 Ìdààmú yóo bá àwọn tí ó ń hun aṣọ funfun, ati àwọn ahunṣọ tí ń lo òwú funfun.
10 Àwọn eniyan pataki ilẹ̀ náà yóo di ẹni ilẹ̀, ìbànújẹ́ yóo sì bá àwọn alágbàṣe.
11 Òmùgọ̀ ni àwọn olórí wọn ní Soani; ìmọ̀ràn wèrè sì ni àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ìgbìmọ̀ Farao ń fún eniyan. Báwo ni eniyan ṣe lè sọ fún Farao pé, “Ọmọ Ọlọ́gbọ́n eniyan ni mí, ọmọ àwọn ọba àtijọ́.”
12 Àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n rẹ dà? Níbo ni wọ́n wà kí wọ́n sọ fún ọ, kí wọ́n sì fi ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun pinnu láti ṣe sí Ijipti hàn ọ́.
13 Àwọn olórí wọn ní Soani ti di òmùgọ̀, àwọn olórí wọn ní Memfisi sì ti gba ẹ̀tàn; àwọn tí wọ́n jẹ́ òpómúléró ní ilẹ̀ Ijipti ti ṣi Ijipti lọ́nà.
14 OLUWA ti dá èdè-àìyedè sílẹ̀ láàrin wọn, wọ́n sì ti ṣi Ijipti lọ́nà ninu gbogbo ìṣe rẹ̀, bí ìgbà tí ọ̀mùtí bá ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n ninu èébì rẹ̀.
15 Kò sí nǹkankan tí ẹnìkan lè ṣe fún Ijipti, kì báà jẹ́ ọlọ́lá tabi mẹ̀kúnnù, kì báà jẹ́ eniyan pataki tabi ẹni tí kò jẹ́ nǹkan.
16 Tí ó bá di ìgbà náà, àwọn ará Ijipti yóo di obinrin. Wọn yóo máa gbọ̀n, fún ẹ̀rù, nígbà tí OLUWA àwọn ọmọ ogun bá gbá wọn mú.
17 Ilẹ̀ Juda yóo di ẹ̀rù fún àwọn ará Ijipti, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóo bẹ̀rù nítorí ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti pinnu láti ṣe sí Ijipti.
18 Tó bá di ìgbà náà, ìlú marun-un yóo wà ní ilẹ̀ Ijipti, tí wọn yóo máa sọ èdè Kenaani; wọ́n óo búra láti jẹ́ ti OLUWA àwọn ọmọ ogun. Orúkọ ọ̀kan ninu wọn yóo máa jẹ́ ìlú Oòrùn.
19 Tó bá di ìgbà náà, wọn yóo tẹ́ pẹpẹ kan fún OLUWA láàrin ilẹ̀ Ijipti, ọ̀wọ̀n OLUWA kan yóo sì wà lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ ààlà ilẹ̀ rẹ̀.
20 Yóo jẹ́ àmì ati ẹ̀rí fún OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ilẹ̀ Ijipti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe OLUWA nítorí àwọn aninilára, OLUWA yóo rán olùgbàlà tí yóo gbà wọ́n sí wọn.
21 OLUWA yóo sọ ara rẹ̀ di mímọ̀ fún àwọn ará Ijipti, wọn óo sì mọ OLUWA nígbà náà. Wọ́n yóo máa sin OLUWA pẹlu ẹbọ ati ẹbọ sísun; wọn óo jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún OLUWA, wọn yóo sì mú ẹ̀jẹ́ náà ṣẹ.
22 OLUWA yóo fìyà jẹ àwọn ará Ijipti ṣugbọn yóo wò wọ́n sàn, wọn yóo pada sọ́dọ̀ OLUWA, yóo gbọ́ adura wọn, yóo sì wò wọ́n sàn.
23 Tó bá di ìgbà náà, ọ̀nà tí ó tóbi kan yóo wà láti Ijipti dé Asiria–àwọn ará Asiria yóo máa lọ sí Ijipti, àwọn ará Ijipti yóo sì máa lọ sí Asiria; àwọn ará Ijipti yóo máa jọ́sìn pẹlu àwọn ará Asiria.
24 Ní àkókò náà, Israẹli yóo ṣìkẹta Ijipti ati Asiria, wọn yóo sì jẹ́ ibukun lórí ilẹ̀ fún àwọn ará Ijipti, àwọn eniyan mi.
25 Tí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti súre fún pé, “Ibukun ni fún Ijipti, àwọn eniyan mi, ati fún Asiria tí mo fi ọwọ́ mi dá, ati fún Israẹli ìní mi.”
1 Ní ọdún tí Sagoni, ọba Asiria, rán olórí ogun rẹ̀ pé kí ó lọ bá ìlú Aṣidodu jagun, tí ó gbógun ti ìlú náà, tí ó sì gbà á,
2 OLUWA sọ fún Aisaya ọmọ Amosi pé, “Dìde, bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ tí o lọ́ mọ́ra, sì bọ́ bàtà tí o wọ̀ sí ẹsẹ̀.” Aisaya bá ṣe bí OLUWA ti wí: ó bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ lára, ó sì bọ́ bàtà kúrò lẹ́sẹ̀. Ó bá bẹ̀rẹ̀ sí rìn kiri ní ìhòòhò, láìwọ bàtà.
3 Lẹ́yìn ọdún mẹta, OLUWA dáhùn pé, “Bí Aisaya, iranṣẹ mi, ti rìn ní ìhòòhò tí kò sì wọ bàtà fún ọdún mẹta yìí, jẹ́ àmì ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí ilẹ̀ Ijipti ati ilẹ̀ Kuṣi:
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Asiria yóo ṣe kó àwọn ará Ijipti ati àwọn ará Kuṣi lẹ́rú, ati ọmọde ati àgbàlagbà wọn, ní ìhòòhò, láì wọ bàtà. A óo bọ́ aṣọ kúrò lára wọn, kí ojú ó lè ti Ijipti.
5 Ìbẹ̀rù-bojo yóo dé ba yín, ojú yóo sì tì yín; nítorí Kuṣi ati Ijipti tí ẹ gbójú lé.
6 Àwọn tí ń gbé etí òkun ilẹ̀ yìí yóo wí ní ọjọ́ náà pé, ‘Ẹ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn tí a gbójú lé, àwọn tí à ń sá tọ̀ lọ pé kí wọ́n ràn wá lọ́wọ́, kí wọ́n gbà wá lọ́wọ́ ọba Asiria. Báwo ní àwa óo ṣe wá là báyìí?’ ”
1 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa aṣálẹ̀ etí òkun nìyí: àjálù kan ń já bọ̀ láti inú aṣálẹ̀, láti ilẹ̀ tí ó bani lẹ́rù, ó ń bọ̀ bí ìjì líle tí ń jà bọ̀ láti ìhà àríwá aṣálẹ̀.
2 Ìran tí a fi hàn mí yìí le: Àwọn oníjàgídíjàgan lọ digun kó ìkógun, abanǹkanjẹ́ sì ba nǹkan jẹ́. Ẹ̀yin ará Elamu, ẹ gòkè lọ! Ẹ̀yin ará Media, ẹ múra ogun! Mo ti fòpin sí òṣé ati ìjìyà tí Babiloni kó bá gbogbo eniyan.
3 Nítorí náà, gbogbo ẹ̀gbẹ́ ní ń dùn mí, gbogbo ara ní ń ro mí bí obinrin tí ń rọbí lọ́wọ́. A tẹrí mi ba kí n má baà gbọ́ nǹkankan, wọ́n dẹ́rù bà mí kí n má baà ríran.
4 Ọkàn mi dààmú, jìnnìjìnnì dà bò mí; wọ́n ti sọ àfẹ̀mọ́júmọ́ tí mò ń retí di ìbẹ̀rù mọ́ mi lọ́wọ́.
5 Wọ́n tẹ́ tabili, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sílẹ̀ wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu. Ariwo bá ta pé “Ẹ gbéra nílẹ̀, ẹ̀yin ológun! Ẹ fepo pa asà yín.”
6 Nítorí OLUWA wí fún mi pé: “Lọ fi aṣọ́nà ṣọ́ ojú ọ̀nà, kí ó máa kéde ohun tí ó bá rí.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn ẹlẹ́ṣin tí wọn ń bọ̀ ní meji-meji, bí ó bá rí i tí àwọn kan gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, tí àwọn kan gun ràkúnmí, kí ó fara balẹ̀ dáradára, kí ó dẹtísílẹ̀ dáradára.”
8 Ẹni tí ń ṣọ́nà kígbe pé: “OLUWA mi, lórí ilé-ìṣọ́ ni èmi í dúró sí lojoojumọ, níbi tí a fi mí ṣọ́, ni èmi í sì í wà ní òròòru.
9 Ẹ wò ó! Àwọn ẹlẹ́ṣin kan ń bọ̀, wọ́n fẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ ní meji-meji!” “Ẹ gbọ́! Ìlú Babiloni ti wó! Ó ti wó! Pẹlu gbogbo àwọn oriṣa rẹ̀, ó ti wó lulẹ̀ patapata.”
10 Ẹ̀yin eniyan mi tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, bí ẹni tẹ ọkà ní ibi ìpakà, ohun tí mo gbọ́ láti ọ̀dọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli, ní mò ń kéde fun yín yìí.
11 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Edomu nìyí: Ẹnìkan ń pè mí láti Seiri Ó ní: “Aṣọ́nà, Òru ti rí o? Aṣọ́nà, àní òru ti rí?”
12 Aṣọ́nà bá dáhùn, ó ní: “Ilẹ̀ ń ṣú, ilẹ̀ sì ń mọ́. Bí ẹ bá tún fẹ́ bèèrè, ẹ pada wá, kí ẹ tún wá bèèrè.”
13 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Arabia nìyí: Ninu igbó Arabia ni ẹ óo sùn, ẹ̀yin èrò ará Didani.
14 Ẹ bu omi wá fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ. Ẹ gbé oúnjẹ pàdé ẹni tí ń sá fógun, ẹ̀yin ará ilẹ̀ Tema.
15 Wọ́n ń sá fún idà, wọ́n sá fún idà lójú ogun. Wọ́n ń sá fún àwọn tafàtafà, wọ́n sá fún líle ogun.
16 OLUWA sọ fún mi pé, “Kí ó tó tó ọdún kan, ní ìwọ̀n ọdún alágbàṣe kan, gbogbo ògo Kedari yóo dópin;
17 díẹ̀ ni yóo sì kù ninu àwọn tafàtafà alágbára ọmọ Kedari; nítorí OLUWA Ọlọrun Israẹli ló sọ bẹ́ẹ̀.”
1 Èyí ni àsọtẹ́lẹ̀ nípa àfonífojì ìran: Kí ni gbogbo yín ń rò tí ẹ fi gun orí òrùlé lọ,
2 ẹ̀yin tí ìlú yín kún fún ariwo, tí ẹ jẹ́ kìkì ìrúkèrúdò ati àríyá? Gbogbo àwọn tí ó kú ninu yín kò kú ikú idà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú lójú ogun.
3 Gbogbo àwọn ìjòyè ìlú yín parapọ̀ wọ́n sálọ, láì ta ọfà ni ọ̀tá mú wọn. Gbogbo àwọn tí wọn rí ni wọ́n mú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti sá jìnnà.
4 Nítorí náà, ni mo ṣe sọ pé, “Ẹ ṣíjú kúrò lára mi ẹ jẹ́ kí n sọkún, kí n dami lójú pòròpòrò, ẹ má ṣòpò pé ẹ óo rẹ̀ mí lẹ́kún, nítorí ìparun àwọn ará Jerusalẹmu, àwọn eniyan mi.”
5 Nítorí OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀, ọjọ́ ìrúkèrúdò ati ìdágìrì ati ìdàrúdàpọ̀, ní àfonífojì ìran. Ọjọ́ wíwó odi ìlú palẹ̀ ati igbe kíké láàrin àwọn òkè ńlá.
6 Àwọn ọmọ ogun Elamu gbé ọfà wọn kọ́ èjìká, pẹlu kẹ̀kẹ́-ogun ati àwọn ẹlẹ́ṣin, àwọn ọmọ ogun Kiri sì tọ́jú asà wọn.
7 Àwọn àfonífojì dáradára yín kún fún kẹ̀kẹ́-ogun àwọn ẹlẹ́ṣin sì dúró sí ipò wọn lẹ́nu ibodè;
8 ó ti tú aṣọ lára Juda. Ní ọjọ́ náà, ẹ gbẹ́kẹ̀lé àwọn ohun ìjà tí ó wà ninu Ilé-Igbó,
9 ẹ rí i pé ibi tí ògiri ìlú Dafidi ti sán pọ̀, ẹ sì gbá omi inú adágún tí ó wà ní ìsàlẹ̀ jọ.
10 Ẹ ka iye ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu, ẹ sì wó àwọn kan palẹ̀ ninu wọn, kí ẹ lè rí òkúta tún odi ìlú ṣe.
11 Ẹ wa kòtò sí ààrin ògiri mejeeji, Kí ẹ lè rí ààyè fa omi inú odò àtijọ́ sí. Ṣugbọn ẹ kò wo ojú ẹni tí ó ṣe ohun tí ń ṣẹlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò bìkítà fún ẹni tí ó ṣètò rẹ̀ láti ìgbà pípẹ́ wá.
12 Ní ọjọ́ náà, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun fi ìpè sóde pé, kí ẹ máa sọkún, kí ẹ máa ṣọ̀fọ̀, kí ẹ fá orí yín, kí ẹ sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 Ṣugbọn dípò kí ẹ ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀ ń yọ̀, inú yín ń dùn. Ẹ̀ ń pa mààlúù, ẹ̀ ń pa aguntan, ẹ̀ ń jẹ ẹran, ẹ̀ ń mu ọtí waini. Ẹ̀ ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á jẹ, kí á mu! Nítorí pé lọ́la ni a óo kú.”
14 OLUWA àwọn ọmọ ogun ti fi tó mi létí pé: “A kò ní dárí ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì yín títí tí ẹ óo fi kú.”
15 OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní, “Lọ bá Ṣebina, iranṣẹ ọba, tí ó jẹ́ olórí ní ààfin ọba, Kí o bi í pé:
16 ‘Kí ni o fẹ́ máa ṣe níhìn-ín? Ta ni o sì ní níhìn-ín tí o fi gbẹ́ ibojì síhìn-ín fún ara rẹ? Ìwọ tí o gbẹ́ ibojì sórí òkè, tí o kọ́ ilé fún ara rẹ ninu àpáta?
17 Wò ó! OLUWA yóo fi tipátipá wọ́ ọ sọnù ìwọ alágbára. Yóo gbá ọ mú tipátipá.
18 Yóo fì ọ́ nàkànnàkàn, yóo sì sọ ọ́ nù bíi bọ́ọ̀lù, sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú, níbẹ̀ ni óo kú sí. Níbẹ̀ ni àwọn kẹ̀kẹ́-ogun rẹ tí ó dára yóo wà, ìwọ tí ò ń kó ìtìjú bá ilé OLUWA rẹ.
19 N óo tì ọ́ kúrò ní ààyè rẹ, n óo fà ọ́ lulẹ̀ kúrò ní ipò rẹ.’
20 “Ní ọjọ́ náà, n óo pe Eliakimu, iranṣẹ mi, ọmọ Hilikaya.
21 N óo gbé aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n óo sì dì í ní àmùrè rẹ; n óo gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́, yóo sì di baba fún àwọn ará Jerusalẹmu ati àwọn ará ilé Juda.
22 N óo fi í ṣe alákòóso ilé Dafidi. Ìlẹ̀kùn tí ó bá ṣí, kò ní sí ẹni tí yóo lè tì í; èyí tí ó bá tì, kò ní sí ẹni tí yóo lè ṣí i.
23 N óo fìdí rẹ̀ múlẹ̀ bí èèkàn tí a kàn mọ́ ilẹ̀ tí ó le, yóo di ìtẹ́ iyì fún ilé baba rẹ̀.
24 “Gbogbo ẹbí rẹ̀ ní agboolé baba rẹ̀ yóo di ẹrú rẹ̀, ati àwọn ọmọ ati àwọn ohun èlò, láti orí ife ìmumi, títí kan ìgò ọtí.”
25 OLUWA àwọn ọmọ-ogun ní, “Ní ọjọ́ náà, èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gbọningbọnin yóo yọ, wọn yóo gé e, yóo sì wó lulẹ̀, ẹrù tí wọn fi kọ́ lórí rẹ̀ yóo sì já dànù.” Bẹ́ẹ̀ ni OLUWA sọ.
1 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Tire nìyí: Ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin ọlọ́kọ̀ ojú omi ìlú Taṣiṣi; nítorí pé Tire ti di ahoro, láìsí ilé tabi èbúté! Ní ilẹ̀ Kipru ni a ti fi eléyìí hàn wọ́n.
2 Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin tí ń gbé etí òkun, ẹ̀yin oníṣòwò ará Sidoni; àwọn iranṣẹ yín ti kọjá sí òdìkejì òkun,
3 wọ́n gba orí alagbalúgbú omi kọjá lọ. Èrè yín ni ọkà ìlú Sihori, ìkórè etí odò Naili. Ẹ̀yin ni ẹ̀ ń ṣòwò káàkiri àgbáyé.
4 Ojú tì ọ́, ìwọ Sidoni nítorí òkun ti fọhùn, agbami òkun ti sọ̀rọ̀, ó ní: “N kò rọbí, bẹ́ẹ̀ ni n kò bímọ; n kò tọ́ àwọn ọmọ dàgbà rí kì báà ṣe ọmọkunrin tabi ọmọbinrin.”
5 Nígbà tí ìròyìn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí Tire bá dé Ijipti àwọn ará Ijipti yóo kérora.
6 Ẹ kọjá lọ sí Taṣiṣi. Ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin tí ó ń gbé etí òkun.
7 Ṣé ìlú olókìkí yín náà nìyí, tí a ti tẹ̀dó láti ìgbà àtijọ́! Tí ó fi ẹsẹ̀ rẹ̀ rìn lọ sí ilẹ̀ òkèèrè, tí ó ṣe àlejò lọ sibẹ!
8 Ta ni ó gbìmọ̀ irú èyí sí Tire, Ìlú tí ń fún àwọn ọba ìlú yòókù ládé? Tí ó jẹ́ pé kìkì ìjòyè ni àwọn oníṣòwò rẹ̀; gbogbo àwọn tí ń ta ọjà níbẹ̀ ni wọ́n jẹ́ ọlọ́lá ní gbogbo ayé.
9 OLUWA àwọn ọmọ ogun ni ó pinnu láti ba gbogbo iyì ògo jẹ, ati láti tẹ́ gbogbo àwọn ọlọ́lá ayé.
10 Ẹ̀yin ará Taṣiṣi, ẹ máa tàn ká orí ilẹ̀ yín títí ẹ ó fi kan odò Naili, kò sí èbúté tí yóo da yín dúró mọ́.
11 OLUWA ti na ọwọ́ rẹ̀ sórí òkun Ó ti mi àwọn orílẹ̀-èdè jìgìjìgì. Ó ti pàṣẹ nípa ilẹ̀ Kenaani pé kí wọ́n pa gbogbo ibi ààbò rẹ̀ run.
12 Ó ní, “Àríyá yín ti dópin, ẹ̀yin ọmọ Sidoni tí à ń ni lára. Ò báà dìde kí o lọ sí Kipru, ara kò ní rọ̀ ọ́ níbẹ̀.”
13 Ẹ wo ilẹ̀ àwọn ará Kalidea! Bí wọ́n ṣe wà bí aláìsí. Àwọn Asiria ti pinnu láti sọ Tire di ibùgbé àwọn ẹranko, wọ́n gbé àkàbà ogun ti odi rẹ̀. Wọ́n fogun kó àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀, wọ́n sì sọ ọ́ di ahoro.
14 Ẹ sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ẹ̀yin ọkọ̀ ojú omi Taṣiṣi, nítorí àwọn ilé ìṣọ́ yín tí ó lágbára ti wó.
15 Nígbà, tó bá yá, Tire yóo di ìgbàgbé fún aadọrin ọdún gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ ọba kan; lẹ́yìn aadọrin ọdún ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí Tire yóo dàbí orin kan tí àwọn aṣẹ́wó máa ń kọ pé:
16 “Mú hapu, kí o máa káàkiri ààrin ìlú, ìwọ aṣẹ́wó, ẹni ìgbàgbé. Máa kọ orin dídùn ní oríṣìíríṣìí, kí á lè ranti rẹ.”
17 Nígbà tí aadọrin ọdún bá pé, OLUWA yóo ranti Tire. Yóo pada sídìí òwò aṣẹ́wó rẹ̀, yóo sì máa bá gbogbo ìjọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ṣe òwò àgbèrè.
18 Yóo ya ọjà tí ó ń tà ati èrè tí ó bá jẹ sọ́tọ̀ fún OLUWA, kò ní máa to èrè rẹ̀ jọ, tabi kí ó máa kó o pamọ́; ṣugbọn yóo máa lò wọ́n láti pèsè oúnjẹ ati aṣọ fún àwọn tí ó bá ń sin OLUWA.
1 Ẹ wò ó! OLUWA yóo fọ́ gbogbo ayé wómúwómú yóo sì sọ ọ́ di ahoro. Yóo dojú rẹ̀ rú, yóo sì fọ́n àwọn eniyan inú rẹ̀ ká.
2 Ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ará ìlú ni yóo ṣẹlẹ̀ sí alufaa; ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí ẹrú yóo ṣẹlẹ̀ sí olówó rẹ̀; ohun tí ó ṣe ọmọ-ọ̀dọ̀ ni yóo ṣe ọ̀gá rẹ̀; ohun tí ó ṣe ẹni tí ń rà ni yóo ṣe ẹni tí ń tà. Ohun tí ó ṣe ẹni tí ń yá ni lówó ni yóo ṣe ẹni tí à ń yá lówó. Ohun tí ó ṣe onígbèsè ni yóo ṣe ẹni tí a jẹ lówó.
3 Ogun yóo kó ilé ayé, yóo di òfo patapata. Nítorí OLUWA ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
4 Ilẹ̀ ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo nǹkan ń rọ. Ayé ń joró, ó sì ń ṣá àwọn ọ̀run ń joró pẹlu.
5 Àwọn tí ń gbé inú ayé ti ba ilé ayé jẹ́, nítorí pé wọ́n ti rú àwọn òfin wọ́n ti tàpá sí àwọn ìlànà wọ́n sì da majẹmu ayérayé.
6 Nítorí náà ègún ń pa ayé run lọ. Àwọn eniyan inú rẹ̀ ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, iná ń jó àwọn olùgbé inú rẹ̀, eniyan díẹ̀ ni ó sì kù.
7 Ọtí waini ń ṣọ̀fọ̀. Igi èso àjàrà ń joró, gbogbo àwọn tí ń ṣe àríyá ti ń kẹ́dùn.
8 Ìró ìlù ayọ̀ ti dákẹ́, ariwo àwọn alárìíyá ti dópin. Àwọn tí ń tẹ dùùrù ti dáwọ́ dúró.
9 Wọn kò mu ọtí níbi tí wọ́n ti ń kọrin mọ́ ọtí líle sì korò lẹ́nu àwọn tí ń mu ún.
10 Ìlú ìdàrúdàpọ̀ ti wó palẹ̀, ó ti dòfo, gbogbo ìlẹ̀kùn ilé ti tì, kò sì sí ẹni tí ó lè wọlé.
11 Ariwo ta lóde nítorí kò sí ọtí waini, oòrùn ayọ̀ ti wọ̀; ayọ̀ di àwátì ní ilẹ̀ náà.
12 Gbogbo ìlú ti di ahoro, wọ́n ti wó ẹnu ibodè ìlú wómúwómú.
13 Bẹ́ẹ̀ ní yóo rí ní ilẹ̀ ayé, láàrin àwọn orílẹ̀-èdè bí igi olifi tí a ti gbọn gbogbo èso rẹ̀ sílẹ̀, lẹ́yìn tí a ti kórè tán ninu ọgbà àjàrà.
14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n ń kọrin ayọ̀, wọ́n ń yin OLUWA lógo láti ìhà ìwọ̀-oòrùn wá.
15 Nítorí náà ẹ fi ògo fún OLUWA ní ìhà ìlà-oòrùn; ẹ̀yin tí ń gbé etí òkun, ẹ fògo fún OLUWA Ọlọrun Israẹli.
16 Láti òpin ayé ni a ti ń gbọ́ ọpọlọpọ orin ìyìn, wọ́n ń fi ògo fún Olódodo. Ṣugbọn èmi sọ pé: “Mò ń rù, mò ń joro, mò ń joro, mo gbé! Nítorí pé àwọn ọ̀dàlẹ̀ ń dalẹ̀, wọ́n ń dalẹ̀, wọ́n ń hùwà àgàbàgebè.”
17 Ẹ̀rù ati kòtò, ati tàkúté ń bẹ níwájú yín ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ilẹ̀ ayé.
18 Ẹni tí ẹ̀rù bá bà tí ó sá, yóo já sinu kòtò, ẹni tí ó bá rá pálá jáde ninu kòtò yóo kó sinu tàkúté. Nítorí pé àwọn fèrèsé ojú ọ̀run ti ṣí, àwọn ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé sì mì tìtì.
19 Ayé ti fọ́, ayé ti fàya, ayé sì mì tìtì.
20 Ayé ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n bí ọ̀mùtí, ó ń mì bí abà oko. Ẹrù ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wọ̀ ọ́ lọ́rùn, ó wó lulẹ̀, kò ní dìde mọ́.
21 Ní àkókò náà, OLUWA yóo fìyà jẹ àwọn ogun ọ̀run, lọ́run; ati àwọn ọba ayé, lórí ilẹ̀ ayé.
22 A óo gbá gbogbo wọn jọ pọ̀ sinu kòtò bí ẹlẹ́wọ̀n, wọn óo wà ní àtìmọ́lé ninu ẹ̀wọ̀n. Lẹ́yìn ọpọlọpọ ọjọ́, a óo fìyà jẹ wọ́n.
23 Òṣùpá yóo dààmú, ìtìjú yóo sì bá oòrùn. Nítorí OLUWA àwọn ọmọ-ogun yóo jọba lórí òkè Sioni ati ní Jerusalẹmu. Yóo sì fi ògo rẹ̀ hàn níwájú àwọn àgbààgbà wọn.
1 OLUWA, ìwọ ni Ọlọrun mi. N óo gbé ọ ga: n óo yin orúkọ rẹ. Nítorí pé o ti ṣe àwọn nǹkan ìyanu, o ti ṣe àwọn ètò láti ìgbà àtijọ́, o mú wọn ṣẹ pẹlu òtítọ́.
2 O sọ àwọn ìlú di òkítì àlàpà o sì ti pa àwọn ìlú olódi run. O wó odi gíga àwọn àjèjì, kúrò lẹ́yìn ìlú, ẹnikẹ́ni kò sì ní tún un kọ́ mọ́.
3 Nítorí náà àwọn alágbára yóo máa yìn ọ́ ìlú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú yóo bẹ̀rù rẹ.
4 Nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi fún talaka, ibi ìsápamọ́sí fún aláìní lákòókò ìṣòro. Ìwọ ni ibi ààbò nígbà òjò, ati ìbòòji ninu oòrùn. Nítorí bí ìjì ti rí lára ògiri bẹ́ẹ̀ ni ibinu aláìláàánú rí;
5 ó dàbí ooru ninu aṣálẹ̀. O pa àwọn àjèjì lẹ́nu mọ́; bí òjìji ìkùukùu tií sé ooru mọ́, bẹ́ẹ̀ ni o ṣe dá orin mọ́ àwọn oníjàgídíjàgan lẹ́nu.
6 OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo fi àwọn ẹran ọlọ́ràá se àsè kan fún gbogbo orílẹ̀-èdè; yóo pa àwọn ẹran àbọ́pa, pẹlu ọtí waini, ẹran àbọ́pa tí ó sanra, tí ó kún fún mùdùnmúdùn, ati ọtí waini tí ó dára.
7 Lórí òkè yìí, OLUWA yóo fa aṣọ tí a ta bo àwọn eniyan lójú ya, àní aṣọ tí a dà bo gbogbo orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀.
8 Yóo gbé ikú mì títí lae, OLUWA yóo nu omijé nù kúrò lójú gbogbo eniyan. Yóo mú ẹ̀gàn àwọn eniyan rẹ̀ kúrò, ní gbogbo ilẹ̀ ayé. OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.
9 Wọn óo máa wí ní ọjọ́ náà pé, “Ọlọrun wa nìyí; a ti ń dúró dè é kí ó lè gbà wá, OLUWA nìyí; òun ni a ti ń dúró dè. Ẹ jẹ́ kí á máa yọ̀, kí inú wa sì dùn nítorí ìgbàlà rẹ̀.”
10 Nítorí OLUWA yóo na ọwọ́ ààbò rẹ̀ sórí òkè yìí. Ṣugbọn àwọn ará Moabu yóo di àtẹ̀mọ́lẹ̀ lórí ilẹ̀ wọ́n, bíi koríko tí a tẹ̀ mọ́lẹ̀ lórí ààtàn.
11 Wọn óo na ọwọ́ ní ààrin rẹ̀ bí ìgbà tí ẹni tí ń lúwẹ̀ẹ́ bá nawọ́ ninu omi. Ṣugbọn OLUWA yóo rẹ ìgbéraga wọn sílẹ̀, ọwọ́ wọn yóo sì rọ.
12 OLUWA yóo bi odi gíga rẹ̀ wó, yóo wó o palẹ̀, yóo sì sọ ọ́ di erùpẹ̀ ilẹ̀.
1 Ní àkókò náà, orin tí wọn óo máa kọ ní ilẹ̀ Juda ni pé: “A ní ìlú tí ó lágbára, ó fi ìgbàlà ṣe odi ati ibi ààbò.
2 Ẹ ṣí ìlẹ̀kùn ibodè, kí orílẹ̀-èdè olódodo, tí ń ṣe òtítọ́ lè wọlé.
3 O óo pa àwọn tí wọ́n gbé ọkàn wọn lé ọ mọ́ ní alaafia pípé, nítorí pé wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọ.
4 Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA títí lae, nítorí àpáta ayérayé ni OLUWA Ọlọrun.
5 Ó sọ àwọn tí ń gbé orí òkè kalẹ̀, ó sọ ìlú tí ó wà ní orí òkè téńté di ilẹ̀, ó sọ ọ́ di ilẹ̀ patapata, ó fà á sọ sinu eruku.
6 Wọ́n ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, bí àwọn òtòṣì tí ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni àwọn aláìní ń tẹ̀ ẹ́.”
7 Ọ̀nà títẹ́jú ni ọ̀nà àwọn olódodo ó mú kí ọ̀nà àwọn olódodo máa dán.
8 Àwa dúró dè ọ́ ní ọ̀nà ìdájọ́ rẹ, OLUWA, orúkọ rẹ ati ìrántí rẹ ni ọkàn wa ń fẹ́.
9 Ọkàn mi ń ṣe àfẹ́rí rẹ lálẹ́, mo sì ń fi tọkàntọkàn wá ọ nítorí nígbà tí ìlànà rẹ bá wà láyé ni àwọn ọmọ aráyé yóo kọ́ òdodo.
10 Bí a bá ṣàánú ẹni ibi, kò ní kọ́ láti ṣe rere. Yóo máa ṣe ibi ní ilẹ̀ àwọn olódodo, kò sì ní rí ọlá ńlá OLUWA.
11 OLUWA o ti gbé ọwọ́ rẹ sókè láti jẹ àwọn ọ̀tá níyà, ṣugbọn wọn kò rí i. Jẹ́ kí wọn rí i pé ọ̀rọ̀ àwọn eniyan rẹ jẹ ọ́ lógún, kí ojú sì tì wọ́n. Jẹ́ kí iná tí o dá fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
12 OLUWA ìwọ yóo fún wa ní alaafia, nítorí pé ìwọ ni o ṣe gbogbo iṣẹ́ wa fún wa.
13 OLUWA, Ọlọrun wa, àwọn oluwa mìíràn ti jọba lórí wa ṣugbọn orúkọ rẹ nìkan ni àwa mọ̀.
14 Wọ́n ti kú, wọn kò ní wà láàyè mọ́, ẹ̀mí wọn kò ní dìde mọ́ ní isà òkú. Nítorí bẹ́ẹ̀ ni o ṣe jẹ wọ́n níyà, o sì pa wọ́n run, o sì ti sọ gbogbo ìrántí wọn di ohun ìgbàgbé.
15 Ṣugbọn ìwọ OLUWA ti mú kí orílẹ̀-èdè náà pọ̀ sí i, OLUWA, o ti bukun orílẹ̀-èdè náà, gbogbo ààlà ilẹ̀ náà ni o ti bì sẹ́yìn, o sì ti buyì kún ara rẹ.
16 OLUWA nígbà tí wọ́n wà ninu ìpọ́njú, wọ́n wá ọ, wọ́n fọkàn gbadura nígbà tí o jẹ wọ́n ní ìyà.
17 Bí aboyún tí ó fẹ́ bímọ, tí ó ń yí, tí ó sì ń ké ìrora, nígbà tí àkókò àtibímọ rẹ̀ súnmọ́ tòsí bẹ́ẹ̀ ni a rí nítorí rẹ, OLUWA.
18 A wà ninu oyún, ara ń ro wá, a ní kí a bí, òfo ló jáde. A kò ṣẹgun ohunkohun láyé bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń gbé ayé kò tíì ṣubú.
19 Àwọn òkú wa yóo jí, wọn óo dìde kúrò ninu ibojì. Ẹ tají kí ẹ máa kọrin, ẹ̀yin tí ó sùn ninu erùpẹ̀. Nítorí pé ìrì ìmọ́lẹ̀ ni ìrì yín, ẹ óo sì sẹ ìrì náà sì ilẹ̀ àwọn òkú.
20 Ẹ gbéra nílẹ̀, ẹ̀yin eniyan mi, ẹ wọ inú yàrá yín, kí ẹ sì ti ìlẹ̀kùn mọ́rí; ẹ farapamọ́ fún ìgbà díẹ̀, títí tí ibinu OLUWA yóo fi kọjá.
21 OLUWA óo yọ láti ibùgbé rẹ̀, láti fi ìyà jẹ àwọn tí ń gbé inú ayé, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ilẹ̀ yóo tú ẹ̀jẹ̀ àwọn tí wọ́n pa sórí rẹ̀ jáde, kò sì ní bo àwọn tí a pa mọ́lẹ̀ mọ́.
1 Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo fi idà rẹ̀ tí ó mú, tí ó tóbi, tí ó sì lágbára, pa Lefiatani, ejò tí ó ń fò, Lefiatani, ejò tí ń lọ́ wérékéké, yóo sì pa ejò ńlá tí ń bẹ ninu òkun.
2 Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo kọrin nípa ọgbà àjàrà dáradára kan pé,
3 “Èmi OLUWA ni olùṣọ́ rẹ̀, lásìkò, lásìkò ni mò ń bomi rin ín; tọ̀sán-tòru ni mò ń ṣọ́ ọ kí ẹnìkan má baà bà á jẹ́.
4 Inú kò bí mi, ǹ bá rí ẹ̀gún ati pàǹtí ninu rẹ̀, ǹ bá gbógun tì wọ́n, ǹ bá jó gbogbo wọn níná papọ̀.
5 Ṣugbọn bí wọn bá fi mí ṣe ààbò, kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa; kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa.”
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóo ta gbòǹgbò, Israẹli yóo tanná, yóo rúwé, yóo so, èso rẹ̀ yóo sì kún gbogbo ayé.
7 Ṣé OLUWA ti jẹ wọ́n níyà bí ó ti fìyà jẹ àwọn tí ó jẹ wọ́n níyà? Ṣé ó ti pa wọ́n bí ó ti pa àwọn tí ó pa wọ́n?
8 OLUWA fìyà jẹ àwọn eniyan rẹ̀, ó kó wọn lọ sí ìgbèkùn; ó lé wọn jáde ní ìlú, bí ìgbà tí ẹ̀fúùfù líle bá ń fẹ́ láti ìlà oòrùn.
9 Ọ̀nà tí a fi lè pa ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu rẹ́, tí a fi lè mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kúrò ni pé: Kí ó fọ́ gbogbo òkúta àwọn pẹpẹ oriṣa rẹ̀ túútúú, bí ẹfun tí a lọ̀ kúnná; kí ó má ku ère oriṣa Aṣera tabi pẹpẹ turari kan lóòró.
10 Nítorí ìlú olódi ti di ahoro, ó di ibùgbé tí a kọ̀ sílẹ̀, tí a sì patì bí aginjù; ibẹ̀ ni àwọn ọmọ mààlúù yóo ti máa jẹko, wọn óo dùbúlẹ̀ níbẹ̀, wọn óo sì máa jẹ àwọn ẹ̀ka igi rẹ̀.
11 Àwọn ẹ̀ka igi náà yóo dá nígbà tí wọ́n bá gbẹ, àwọn obinrin yóo sì fi wọ́n dáná. Nítorí òye kò yé àwọn eniyan wọnyi rárá; nítorí náà, ẹni tí ó dá wọn kò ní ṣàánú wọn, Ẹni tí ó mọ wọ́n kò ní yọ́nú sí wọn.
12 Ní ọjọ́ náà, OLUWA yóo pa ẹ̀yin eniyan Israẹli bí ẹni pa ọkà, láti odò Yufurate títí dé odò Ijipti, yóo sì ko yín jọ lọ́kọ̀ọ̀kan.
13 Ní ọjọ́ náà, a óo fun fèrè ogun ńlá, àwọn tí ó ti sọnù sí ilẹ̀ Asiria ati àwọn tí a lé lọ sí ilẹ̀ Ijipti yóo wá sin OLUWA lórí òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.
1 Adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí Efuraimu gbé! Ẹwà ògo rẹ̀ tí ń ṣá bí ìtànná náà gbé! Ìlú tí ó wà ní òkè àfonífojì dáradára, ohun àmúyangàn fún àwọn tí ó mutí yó.
2 Wò ó! OLUWA ní ẹnìkan, tí ó lágbára bí ẹ̀fúùfù líle, ati bí ìjì apanirun, bí afẹ́fẹ́ òjò tí ó lágbára tí àgbàrá rẹ̀ ṣàn kọjá bèbè; ẹni náà yóo bì wọ́n lulẹ̀.
3 Ẹsẹ̀ ni yóo fi tẹ adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí ilẹ̀ Efuraimu.
4 Ògo rẹ̀ tí ń ṣá bí òdòdó tí ó wà ní òkè àfonífojì dáradára, yóo dàbí àkọ́so èso ọ̀pọ̀tọ́, tí ó pọ́n ṣáájú ìgbà ìkórè. Ẹni tó bá rí i yóo sáré sí i, yóo ká a, yóo sì jẹ ẹ́.
5 Ní ọjọ́ náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo jẹ́ adé ògo ati adé ẹwà, fún àwọn tí ó kù ninu àwọn eniyan rẹ̀.
6 Yóo jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ fún adájọ́ tí ó jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́, yóo jẹ́ agbára fún àwọn tí ó ń lé ogun sẹ́yìn lẹ́nu ibodè.
7 Ọtí waini ń ti àwọn wọnyi, ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n. Ọtí líle ń ti alufaa ati wolii, ọtí waini kò jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tí wọ́n ń ṣe mọ́. Ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n; wọ́n ń ríran èké, wọ́n ń dájọ́ irọ́.
8 Nítorí èébì kún orí gbogbo tabili oúnjẹ, gbogbo ilẹ̀ sì kún fún ìdọ̀tí
9 Wọ́n ń sọ pé, “Ta ni yóo kọ́ lọ́gbọ́n? Ta sì ni yóo jíṣẹ́ náà fún? Ṣé àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbọyàn lẹ́nu wọn, àbí àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ já lẹ́nu ọmú?
10 Nítorí pé gbogbo rẹ̀ tòfin-tòfin ni, èyí òfin, tọ̀hún ìlànà. Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún.”
11 Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn àjèjì tí èdè wọn yàtọ̀ ni OLUWA yóo lò láti bá àwọn eniyan wọnyi sọ̀rọ̀.
12 Àwọn tí ó ti wí fún pé: Ìsinmi nìyí, ẹ fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní ìsinmi; ìtura nìyí. Sibẹsibẹ wọ́n kọ̀, wọn kò gbọ́.
13 Nítorí náà ọ̀rọ̀ OLUWA sí wọn yóo jẹ́ tòfin-tòfin, èyí òfin tọ̀hún ìlànà. Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún, kí wọ́n baà lè lọ ṣubú sẹ́yìn kí wọ́n sì fọ́ wẹ́wẹ́; kí á lè dẹ tàkúté sílẹ̀ fún wọn, kí ọwọ́ lè tẹ̀ wọ́n.
14 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí, ẹ̀yin oníyẹ̀yẹ́ eniyan, tí ẹ̀ ń ṣe àkóso àwọn eniyan wọnyi ní Jerusalẹmu.
15 Nítorí ẹ wí pé: “A ti bá ikú dá majẹmu, a sì ti bá ibojì ṣe àdéhùn. Nígbà tí jamba bá ń bọ̀, kò ní dé ọ̀dọ̀ wa; nítorí a ti fi irọ́ ṣe ibi ìsádi wa, a sì ti fi èké ṣe ibi ààbò.”
16 Nítorí náà OLUWA Ọlọrun sọ pé, “Wò ó! Èmi yóo ri òkúta ìpìlẹ̀ ilé kan mọ́lẹ̀ ní Sioni, yóo jẹ́ òkúta tí ó lágbára, òkúta igun ilé iyebíye, tí ó ní ìpìlẹ̀ tí ó dájú: Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, ojú kò níí kán an.
17 Ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ni n óo fi ṣe okùn ìwọnlẹ̀, òdodo ni n óo fi ṣe ìwọ̀n ògiri.” Òjò àdàpọ̀ mọ́ yìnyín yóo gbá ibi ààbò irọ́ dànù, omi yóo sì bo ibi tí wọ́n sápamọ́ sí.
18 Majẹmu tí ẹ bá ikú dá yóo wá di òfo, àdéhùn yín pẹlu ibojì yóo sì di asán. Nígbà tí jamba bá ń ṣẹlẹ̀ káàkiri, yóo máa dé ba yín.
19 Gbogbo ìgbà tí ó bá ti ń ṣẹlẹ̀ ni yóo máa ba yín tí yóo máa gba yín lọ. Yóo máa ṣẹlẹ̀ láàárọ̀, yóo sì máa ṣẹlẹ̀ tọ̀sán-tòru. Ẹ̀rù yóo ba eniyan, tí eniyan bá mọ ìtumọ̀ ìkìlọ̀ náà.
20 Ibùsùn kò ní na eniyan tán. Bẹ́ẹ̀ ni aṣọ ìbora kò ní fẹ̀ tó eniyan bora.
21 Nítorí pé OLUWA yóo dìde bí ó ti ṣe ní òkè Firasi, yóo bínú bí ó ti bínú ní àfonífojì Gibeoni. Yóo ṣe ohun tí ó níí ṣe, ohun tí yóo ṣe yóo jọni lójú; yóo ṣe iṣẹ́ rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ yóo ṣe àjèjì.
22 Nítorí náà ẹ má ṣe yẹ̀yẹ́, kí á má baà so ẹ̀wọ̀n yín le. Nítorí mo ti gbọ́ ìkéde ìparun, tí OLUWA àwọn ọmọ ogun pinnu láti mú wá sórí ilẹ̀ ayé.
23 Ẹ fetí sílẹ̀ kí ẹ gbọ́ ohùn mi, ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,
24 ṣé ẹni tí ń kọ ilẹ̀ tí ó fẹ́ gbin ohun ọ̀gbìn lè máa kọ ọ́ lọ láì dáwọ́ dúró? Àbí ó lè máa kọ ebè lọ láì ní ààlà?
25 Ṣugbọn bí ó bá ti tọ́jú oko rẹ̀ tán, ṣé kò ní fọ́n èso dili ati èso Kumini sinu rẹ̀, kí ó gbin alikama lẹ́sẹẹsẹ; kí ó gbin ọkà baali sí ibi tí ó yẹ, kí ó sì gbin oríṣìí ọkà mìíràn sí ààlà oko rẹ̀?
26 Yóo ṣe iṣẹ́ rẹ̀ létòlétò bí ó ti yẹ, nítorí pé Ọlọrun rẹ̀ ní ń kọ́ ọ.
27 Àgbẹ̀ kì í fi òkúta ńlá ṣẹ́ ẹ̀gúsí, bẹ́ẹ̀ ni kò ní fi kùmọ̀, lu kumini. Ọ̀pá ni wọ́n fí ń lu ẹ̀gúsí; igi lásán ni wọ́n fí ń lu kumini.
28 Ǹjẹ́ eniyan a máa fi kùmọ̀ lọ ọkà alikama tí wọ́n fi ń ṣe burẹdi? Rárá, ẹnìkan kì í máa pa ọkà títí kí ó má dáwọ́ dúró. Bó ti wù kí eniyan fi ẹṣin yí ẹ̀rọ ìpakà lórí ọkà alikama tó, ẹ̀rọ ìpakà kò lè lọ ọkà kúnná.
29 Ọ̀dọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun ni ìmọ̀ yìí ti ń wá pẹlu, ìmọ̀ràn rẹ̀ yani lẹ́nu; ọgbọ́n rẹ̀ ni ó sì ga jùlọ.
1 Ó ṣe fún Arieli, Jerusalẹmu, ìlú tí ń jẹ́ pẹpẹ Ọlọrun! Ìlú tí Dafidi pàgọ́ sí. Ẹ ṣe ọdún kan tán, ẹ tún ṣe òmíràn sí i, ẹ máa ṣe àwọn àjọ̀dún ní gbogbo àkókò wọn.
2 Sibẹsibẹ n óo mú ìpọ́njú bá ìlú tí ń jẹ́ pẹpẹ Ọlọrun. Ìkérora ati ìpohùnréré ẹkún yóo wà ninu rẹ̀, bíi Arieli ni yóo sì rí sí mi.
3 N óo jẹ́ kí ogun dó tì yín yíká n óo fi àwọn ilé ìṣọ́ ka yín mọ́; n óo sì mọ òkítì sára odi yín.
4 Ninu ọ̀gbun ilẹ̀ ni a óo ti máa gbóhùn rẹ̀, láti inú erùpẹ̀ ni a óo ti máa gbọ́, tí yóo máa sọ̀rọ̀. A óo máa gbọ́ ohùn rẹ̀ láti inú ilẹ̀ bí ohùn òkú, a óo sì máa gbọ́ tí yóo máa sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ láti inú erùpẹ̀.
5 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóo pọ̀ bí iyanrìn, ogunlọ́gọ̀ àwọn aláìláàánú yóo bò ọ́ bí ìyàngbò tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ.
6 Lójijì, kíá, OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo dé ba yín, pẹlu ààrá, ati ìdágìrì, ati ariwo ńlá; ati ààjà, ati ìjì líle, ati ahọ́n iná ajónirun.
7 Ogunlọ́gọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí ń bá ìlú tí ń jẹ́ pẹpẹ Ọlọrun jà, yóo parẹ́ bí àlá, gbogbo àwọn tí ń bá ìlú olódi rẹ jà, tí wọn ń ni í lára yóo parẹ́ bí ìran òru.
8 Bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa bá lá àlá pé òun ń jẹun, tí ó jí, tí ó rí i pé ebi sì tún pa òun, tabi tí ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ́ lá àlá pé òun ń mu omi ṣugbọn tí ó jí, tí ó rí i pé òùngbẹ ṣì ń gbẹ òun, bẹ́ẹ̀ ni yóo rí fún ogunlọ́gọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá Jerusalẹmu jà.
9 Ẹ sọ ara yín di òmùgọ̀, kí ẹ sì máa ṣe bí òmùgọ̀. Ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ sì di afọ́jú. Ẹ mu àmuyó, ṣugbọn kì í ṣe ọtí. Ẹ máa ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n láì mu ọtí líle.
10 Nítorí OLUWA ti fi ẹ̀mí oorun àsùnwọra si yín lára Ó ti di ẹ̀yin wolii lójú; ó ti bo orí ẹ̀yin aríran.
11 Gbogbo ìran yìí sì ru yín lójú, bí ọ̀rọ̀ inú ìwé tí a fi èdìdì dì. Nígbà tí wọ́n gbé e fún ọ̀mọ̀wé tí wọ́n ní, “Jọ̀wọ́ bá wa kà á.” Ó ní òun kò lè kà á nítorí pé wọ́n ti fi èdìdì dì í.
12 Nígbà tí wọ́n gbé e fún ẹni tí kò mọ̀wé tí wọ́n ní, “Jọ̀wọ́ bá wa kà á.” Ó ní òun kò mọ̀wé kà.
13 OLUWA ní, “Nítorí pé ẹnu nìkan ni àwọn eniyan wọnyi fi ń súnmọ́ mi, ètè lásán ni wọ́n sì fi ń yìn mí; ṣugbọn ọkàn wọn jìnnà sí mi. Òfin eniyan, tí wọn kọ́ sórí lásán, ni ìbẹ̀rù mi sì jẹ́ fún wọn.
14 Nítorí náà n óo tún ṣe ohun ìyanu sí àwọn eniyan wọnyi, ohun ìyanu tí ó jọni lójú. Ọgbọ́n yóo parẹ́ mọ́ àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ninu, ìmọ̀ràn yóo sì parẹ́ mọ́ àwọn ọ̀mọ̀ràn níkùn.”
15 Àwọn tí wọ́n fi èrò wọn pamọ́ fún OLUWA gbé; àwọn tí iṣẹ́ wọn jẹ́ iṣẹ́ òkùnkùn, tí ń wí pé, “Ta ló rí wa? Ta ló mọ̀ wá?”
16 Ẹ dorí gbogbo nǹkan kodò. Ṣé eniyan lè sọ amọ̀kòkò di amọ̀? Kí nǹkan tí eniyan ṣe, wí nípa ẹni tí ó ṣe é pé: “Kìí ṣe òun ló ṣe mí.” Tabi kí nǹkan tí eniyan dá sọ nípa ẹni tí ó dá a pé: “Kò ní ìmọ̀.”
17 Ṣebí díẹ̀ ṣínún ló kù tí a óo sọ Lẹbanoni di ọgbà igi eléso a óo sì máa pe ọgbà igi eléso náà ní igbó.
18 Ní ọjọ́ náà, odi yóo gbọ́ ohun tí a kọ sinu ìwé, ojú afọ́jú yóo ríran, ninu òkùnkùn biribiri rẹ̀.
19 Àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóo tún láyọ̀ láti ọ̀dọ̀ OLUWA. Àwọn aláìní yóo máa yọ̀ ninu Ẹni Mímọ́ Israẹli
20 nítorí pé àwọn aláìláàánú yóo di asán, àwọn apẹ̀gàn yóo di òfo; àwọn tí ń wá ọ̀nà láti ṣe ibi yóo parun;
21 àwọn tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu sọ eniyan di ẹlẹ́ṣẹ̀, tí ń dẹ tàkúté sílẹ̀ fún ẹni tí ń tọ́ni sọ́nà, tí wọ́n sì ń fi àbòsí tí kò nídìí ti olódodo sí apá kan.
22 Nítorí náà, OLUWA tí ó ra Abrahamu pada sọ nípa ilé Jakọbu pé, “Ojú kò ní ti Jakọbu mọ́ bẹ́ẹ̀ ni ojú rẹ̀ kò ní rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
23 Nítorí nígbà tí ó bá rí àwọn ọmọ rẹ̀, tíí ṣe iṣẹ́ ọwọ́ mi láàrin wọn, wọn óo fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi. Wọn óo bọ̀wọ̀ fún Ẹni Mímọ́ Jakọbu; wọn óo sì bẹ̀rù Ọlọrun Israẹli.
24 Àwọn tí ó ti ṣìnà ninu ẹ̀mí yóo ní òye; àwọn tí ń kùn yóo sì gba ẹ̀kọ́.”
1 OLUWA ní: “Àwọn ọmọ aláìgbọràn gbé. Àwọn tí wọn ń dá àbá tí ó yàtọ̀ sí tèmi, tí wọn ń kó ẹgbẹ́ jọ, ṣugbọn tí kìí ṣe nípa ẹ̀mí mi; kí wọ́n lè máa dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀.
2 Wọ́n múra, wọ́n gbọ̀nà Ijipti láì bèèrè ìmọ̀ràn lọ́dọ̀ mi. Wọ́n lọ sápamọ́ sí abẹ́ ààbò Farao, wọ́n lọ wá ààbò ní Ijipti.
3 Nítorí náà, ààbò Farao yóo di ìtìjú fún wọn, ibi ìpamọ́ abẹ́ Ijipti yóo di ìrẹ̀sílẹ̀ fún wọn.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn olórí wọn ti lọ sí Soani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé Hanesi.
5 Ojú yóo tì wọ́n, nítorí wọn ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ sọ́dọ̀ àwọn tí kò lè ràn wọ́n lọ́wọ́. Wọn kò lè rí ìrànwọ́ tabi anfaani kankan níbẹ̀, bíkòṣe ìtìjú ati ẹ̀gàn.”
6 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa àwọn ẹranko ilẹ̀ Nẹgẹbu nìyí: “Wọ́n di àwọn nǹkan ìní wọn sí ẹ̀yìn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì di ìṣúra wọn sí ẹ̀yìn ràkúnmí. Wọ́n ń la ilẹ̀ ìṣòro ati wahala kọjá. Ilẹ̀ àwọn akọ kinniun ati abo kinniun, ilẹ̀ paramọ́lẹ̀ ati ejò amúbíiná tí ń fò. Wọ́n ń lọ sọ́dọ̀ àwọn eniyan tí kò lè ṣe wọ́n ní anfaani.
7 Nítorí ìmúlẹ̀mófo ni ìrànwọ́ Ijipti. Nítorí náà ni mo ṣe pè é ní, ‘Rahabu tí ń jókòó lásán.’ ”
8 Nisinsinyii lọ kọ ọ́ sílẹ̀ níwájú wọn, kí o sì kọ ọ́ sinu ìwé, kí ó lè wà títí di ẹ̀yìn ọ̀la, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí lae;
9 nítorí aláìgbọràn eniyan ni wọ́n, Òpùrọ́ ọmọ tí kìí fẹ́ gbọ́ ìtọ́ni OLUWA.
10 Wọ́n á máa sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ríran mọ.” Wọ́n á sì máa sọ fún àwọn wolii pé, “Ẹ má sọ àsọtẹ́lẹ̀ òtítọ́ fún wa mọ́, ọ̀rọ̀ dídùn ni kí ẹ máa sọ fún wa, kí ẹ sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn fún wa.
11 Ẹ fi ojú ọ̀nà sílẹ̀, ẹ yà kúrò lójú ọ̀nà, ẹ má sọ nípa Ẹni Mímọ́ Israẹli fún wa mọ́.”
12 Nítorí náà, Ẹni Mímọ́ Israẹli ní: “Nítorí pé ẹ kẹ́gàn ọ̀rọ̀ yìí, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ìninilára ati ẹ̀tàn, ẹ sì gbára lé wọn,
13 nítorí náà, ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ̀ ń dá yìí; yóo dàbí ògiri gíga tí ó là, tí ó sì fẹ́ wó; lójijì ni yóo wó lulẹ̀ lẹ́ẹ̀kanṣoṣo.
14 Wíwó rẹ̀ yóo dàbí ìgbà tí eniyan la ìkòkò mọ́lẹ̀, tí ó fọ́ yángá-yángá, tóbẹ́ẹ̀ tí eniyan kò rí àpáàdì kan mú jáde ninu rẹ̀, tí a lè fi fọn iná ninu ààrò, tabi èkúfọ́, tí a lè fi bu omi ninu odò.”
15 Nítorí OLUWA Ọlọrun, Ẹni Mímọ́ Israẹli ní: “Bí ẹ bá yipada, tí ẹ sì farabalẹ̀, ẹ óo rí ìgbàlà; bí ẹ bá dákẹ́ jẹ́ẹ́ tí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọrun, ẹ óo lágbára. Ṣugbọn ẹ kọ̀.
16 Ẹ sọ pé ó tì o, ẹ̀yin óo gun ẹṣin sálọ ni. Nítorí náà sísá ni ẹ óo sálọ. Ẹ sọ pé ẹṣin tí ó lè sáré ni ẹ óo gùn. Nítorí náà àwọn tí yóo máa le yín, wọn óo lè sáré gan-an ni.
17 Ẹgbẹrun ninu yín yóo sá fún ẹyọ ọ̀tá yín kan, gbogbo yín yóo sì sá fún ẹyọ eniyan marun-un títí tí àwọn tí yóo kú ninu yín yóo fi dàbí igi àsíá lórí òkè. Wọn óo dàbí àsíá ati àmì lórí òkè.”
18 Nítorí náà OLUWA ń dúró dè yín, ó ti ṣetán láti ṣàánú yín. Yóo dìde, yóo sì ràn yín lọ́wọ́. Nítorí Ọlọrun Olódodo ni OLUWA.
19 Ẹ̀yin ará Sioni tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu, ẹ kò ní sọkún mọ́. OLUWA yóo ṣàánú yín nígbà tí ẹ bá ké pè é, yóo sì da yín lóhùn nígbà tí ó bá gbọ́ igbe yín.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé OLUWA yóo jẹ́ kí ẹ ní ọpọlọpọ ìṣòro, yóo sì jẹ́ kí ẹ ṣe ọpọlọpọ wahala, sibẹsibẹ olùkọ́ yín kò ní farapamọ́ fun yín mọ́, ṣugbọn ẹ óo máa fi ojú yín rí i.
21 Bí ẹ bá fẹ́ yapa sí apá ọ̀tún tabi apá òsì, ẹ óo máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn yín tí yóo máa wí pé, “Ọ̀nà nìyí, ibí ni kí ẹ gbà.”
22 Àwọn oriṣa tí ẹ yọ́ fadaka bò, ati àwọn ère tí ẹ yọ́ wúrà bò yóo di nǹkan èérí lójú yín. Ẹ óo kọ̀ wọ́n sílẹ̀ bí nǹkan aláìmọ́. Ẹ óo sì wí fún wọn pé, “Ẹ pòórá!”
23 OLUWA yóo sì fi òjò ibukun sí orí èso tí ẹ gbìn sinu oko, nǹkan ọ̀gbìn yín yóo sì so lọpọlọpọ. Ní àkókò náà, àwọn ẹran ọ̀sìn yín tí yóo máa jẹ ní pápá oko yóo pọ̀.
24 Àwọn mààlúù ati kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ẹ fí ń ṣe iṣẹ́ lóko yóo máa jẹ oko tí a fi iyọ̀ sí; tí a ti gbọn ìdọ̀tí kúrò lára rẹ̀.
25 Omi yóo máa ṣàn jáde láti orí gbogbo òkè gíga ati gbogbo òkè ńlá, ní ọjọ́ tí ọpọlọpọ yóo kú, nígbà tí ilé ìṣọ́ bá wó lulẹ̀.
26 Òṣùpá yóo mọ́lẹ̀ bí oòrùn; oòrùn yóo mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po meje, ní ọjọ́ tí OLUWA yóo bá di ọgbẹ́ àwọn eniyan rẹ̀, tí yóo sì wo ọgbẹ́ tí ó dá sí wọn lára sàn.
27 Ẹ wo OLUWA tí ń bọ̀ láti ilẹ̀ òkèèrè, ó ń bọ̀ tìbínú-tìbínú; ninu èéfín ńlá tí ń lọ sókè. Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kún fún ibinu; ahọ́n rẹ̀ dàbí iná tí ń jóni run.
28 Èémí rẹ̀ dàbí odò tí ó ṣàn kọjá bèbè rẹ̀ tí ó lè mu eniyan dé ọrùn. Yóo fi ajọ̀ ìparun jọ àwọn orílẹ̀-èdè, yóo sì fi ìjánu tí ń múni ṣìnà bọ àwọn eniyan lẹ́nu.
29 Ẹ óo kọ orin kan bí orin alẹ́ ọjọ́ àjọ̀dún mímọ́, inú yín yóo sì dùn bíi ti ẹni tí ń jó ijó fèrè lọ sórí òkè OLUWA, àpáta Israẹli.
30 OLUWA yóo jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ó lógo, yóo sì jẹ́ kí ẹ rí ọwọ́ rẹ̀ tí yóo fà yọ pẹlu ibinu ńlá ati ninu iná ajónirun; pẹlu ẹ̀fúùfù ati ìjì líle ati òjò yìnyín.
31 Ìbẹ̀rù-bojo yóo mú àwọn ará Asiria nígbà tí wọ́n bá gbóhùn OLUWA, nígbà tí ó bá fi kùmọ̀ rẹ̀ lù wọ́n.
32 Ìró ọ̀pá tí OLUWA yóo fi nà wọ́n yóo dàbí ìró aro ati dùùrù. OLUWA yóo dojú ogun kọ wọ́n.
33 Nítorí pé a ti pèsè iná ìléru sílẹ̀ láti ìgbà àtijọ́ fún ọba Asiria; iná ńlá tí ń jó pẹlu ọpọlọpọ igi. Èémí OLUWA tó dàbí ìṣàn imí-ọjọ́ ni yóo ṣá iná sí i.
1 Àwọn tí ó ń lọ sí Ijipti fún ìrànlọ́wọ́ gbé! Àwọn tí wọ́n gbójú lé ẹṣin; tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé kẹ̀kẹ́ ogun nítorí pé wọ́n pọ̀, tí wọ́n gbójú lé ẹṣin nítorí pé wọ́n lágbára! Wọn kò gbójú lé Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn kò sì wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ OLUWA.
2 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbọ́n, ó sì mọ ọ̀nà tí ó fi lè mú kí àjálù dé bá eniyan, kì í sọ̀rọ̀ tán, kó yí ọ̀rọ̀ rẹ̀ pada. Ṣugbọn yóo dìde sí ìdílé àwọn aṣebi, ati àwọn tí ń ti àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ lẹ́yìn.
3 Eniyan sá ni àwọn ará Ijipti, wọn kìí ṣe Ọlọrun. Ẹranko lásán sì ni ẹṣin wọn wọn kì í ṣe àǹjọ̀nnú. Bí OLUWA bá na ọwọ́, tí ó bá gbá wọn mú, ẹni tí ń ranni lọ́wọ́ yóo fẹsẹ̀ kọ, ẹni tí à ń ràn lọ́wọ́ yóo ṣubú; gbogbo wọn yóo sì jọ ṣègbé pọ̀.
4 Nítorí OLUWA sọ fún mi pé, “Bí kinniun tabi ọmọ kinniun ti máa ń kùn lórí ẹran tí ó bá pa, tí kìí bìkítà fún igbe àwọn olùṣọ́ aguntan, tí wọ́n pera wọn jọ, tí wọn ń bọ̀, tí ẹ̀rù ariwo wọn kìí sìí bà á; bẹ́ẹ̀ ni OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo sọ̀kalẹ̀, yóo wá jà lórí òkè Sioni ati àwọn òkè tí ó yí Sioni ká.
5 Bí àwọn ẹyẹ tií da ìyẹ́ bo ìtẹ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo dáàbò bo Jerusalẹmu, yóo dáàbò bò ó, yóo sì gbà á sílẹ̀ yóo dá a sí, yóo sì yọ ọ́ kúrò ninu ewu.”
6 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ pada sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣàìgbọràn sí lọpọlọpọ.
7 Nítorí pé ní ọjọ́ náà, olukuluku yóo gbé àwọn ère fadaka ati ère wúrà tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe sọnù, àwọn ère tí ó mú wọn dẹ́ṣẹ̀.
8 Idà ni yóo pa Asiria, ṣugbọn kì í ṣe láti ọwọ́ eniyan; idà tí kò ní ọwọ́ eniyan ninu ni yóo pa á run. Yóo sá lójú ogun, a óo sì kó àwọn ọmọkunrin rẹ̀ lọ máa ṣiṣẹ́ tipátipá.
9 Ẹ̀rù yóo ba ọba Asiria, yóo sálọ. Ìpayà yóo mú kí àwọn ọ̀gágun rẹ̀ ju àsíá sílẹ̀. OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀, OLUWA tí iná rẹ̀ wà ní Sioni, tí ojú ààrò rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.
1 Wò ó! Ọba kan yóo jẹ pẹlu òdodo, àwọn ìjòyè yóo sì máa ṣe àkóso pẹlu ẹ̀tọ́.
2 Olukuluku yóo dàbí ibi ààbò nígbà tí ẹ̀fúùfù bá ń fẹ́ ati ibi ìsásí nígbà tí ìjì bá ń jà Wọ́n óo dàbí odò ninu aṣálẹ̀, ati bí ìbòòji àpáta ńlá nílẹ̀ olóoru.
3 Àwọn tí wọ́n bá rí i kò ní dijú sí i, etí àwọn tí ó gbọ́ ọ kò ní di.
4 Àwọn tí kò ní àròjinlẹ̀ tẹ́lẹ̀ yóo ní òye, àwọn akólòlò yóo sì sọ̀rọ̀ ketekete.
5 A kò ní máa pe aláìgbọ́n ní ọlọ́lá mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní máa pe abàlújẹ́ ní eniyan pataki.
6 Nítorí pé aláìgbọ́n ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀, ọkàn rẹ̀ sì ń pète ibi. Ó ń ro bí yóo ṣe hùwà ẹni tí kò mọ Ọlọrun, tí yóo sọ̀rọ̀ ìsọkúsọ sí OLUWA; tí yóo fi ẹni tí ebi ń pa sílẹ̀, láì fún un ní oúnjẹ, tí yóo sì fi omi du ẹni òùngbẹ ń gbẹ.
7 Kìkì ibi ni èrò inú àwọn eniyankeniyan. Wọn a máa pète ìkà, láti fi irọ́ pa àwọn talaka run, kì báà jẹ́ pé ẹjọ́ aláìní jàre.
8 Ṣugbọn eniyan rere a máa ro èrò rere, ìdí nǹkan rere ni à á sì í bá wọn.
9 Ẹ dìde, ẹ̀yin obinrin tí ara rọ̀, ẹ gbóhùn mi; ẹ̀yin ọmọbinrin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra, ẹ tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi.
10 Ní nǹkan bíi ọdún kan ó lé díẹ̀ sí i ẹ̀yin obinrin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra; ẹ ó rí ìdààmú nítorí pé àkókò ìkórè yóo kọjá, èso àjàrà kò sì ní sí lórí igi mọ́.
11 Ẹ gbọ̀n jìnnìjìnnì, ẹ̀yin obinrin tí ara rọ̀, kí wahala ba yín, ẹ̀yin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra, ẹ tú aṣọ yín, kí ẹ wà ní ìhòòhò; kí ẹ sì ró aṣọ ọ̀fọ̀.
12 Ẹ káwọ́ lérí, kí ẹ káàánú nítorí àwọn oko dáradára, ati nítorí àwọn àjàrà eléso;
13 nítorí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n ati ẹ̀gún ọ̀gàn ni ó ń hù lórí ilẹ̀ àwọn eniyan mi. Bákan náà, ẹ káàánú fún àwọn ilé aláyọ̀ ninu ìlú tí ó kún fún ayọ̀,
14 nítorí pé àwọn eniyan yóo sá kúrò ní ààfin, ìlú yóo tú, yóo di ahoro. Òkè ati ilé ìṣọ́ yóo di ibùgbé àwọn ẹranko títí lae, yóo di ibi ìgbádùn fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́, ati pápá ibùjẹ fún àwọn ẹran ọ̀sìn.
15 Bẹ́ẹ̀ ni nǹkan yóo rí, títí ẹ̀mí óo fi bà lé wa láti òkè ọ̀run wá títí aṣálẹ̀ yóo fi di ọgbà eléso, tí ọgbà eléso yóo sì fi di igbó.
16 A óo máa ṣe ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ní gbogbo ilẹ̀ náà, ìwà òdodo yóo sì wà níbi gbogbo.
17 Àyọrísí òdodo yóo sì jẹ́ alaafia, ìgbẹ̀yìn rẹ̀ yóo sì jẹ́ ìbàlẹ̀ àyà wa, ati igbẹkẹle OLUWA títí lae.
18 Àwọn eniyan mi yóo máa gbé pẹlu alaafia, ní ibùgbé tí ó ní ààbò ati ibi ìsinmi tí ó ní ìbàlẹ̀ àyà.
19 Yìnyín yóo bọ́, yóo bo gbogbo ilẹ̀, a óo sì pa ìlú náà run patapata.
20 Ayọ̀ ẹ̀yin tí ẹ̀ ń fúnrúgbìn sí etí odò yóo pọ̀, ẹ̀yin tí ẹ ní mààlúù ati kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ń jẹ káàkiri.
1 O gbé! Ìwọ tí ń panirun, tí ẹnìkan kò parun, ìwọ tí ò ń hùwà ọ̀dàlẹ̀ nígbà tí ẹnìkan kò dà ọ́. Ìgbà tí o bá dáwọ́ ìpanirun dúró, nígbà náà ni a óo pa ìwọ gan-an run; nígbà tí o bá fi ìwà ọ̀dàlẹ̀ sílẹ̀, nígbà náà ni a óo dà ọ́.
2 Ṣàánú wa OLUWA, ìwọ ni a dúró tí à ń wò. Máa ràn wá lọ́wọ́ lojoojumọ, sì máa jẹ́ olùgbàlà wa nígbà ìṣòro.
3 Àwọn orílẹ̀-èdè sá nígbà tí wọ́n gbọ́ ariwo tí ó dàbí ti ààrá, wọ́n fọ́n ká nígbà tí o gbéra nílẹ̀.
4 A kó ìkógun jọ bí ìgbà tí tata bo oko, àwọn eniyan dà bo ìṣúra, bí ìgbà tí eṣú bo oko.
5 A gbé OLUWA ga! Nítorí pé ibi gíga ni ó ń gbé; yóo mú kí ìdájọ́ òtítọ́ ati òdodo kún Sioni.
6 Yóo mú kí ìdúróṣinṣin wà ní gbogbo àkókò rẹ̀. Yóo fún ọ ní ọpọlọpọ ìgbàlà, ati ọgbọ́n, ati ìmọ̀, ìbẹ̀rù OLUWA ni ìṣúra rẹ̀.
7 Ẹ wò ó, àwọn alágbára ń kígbe lóde, àwọn òjíṣẹ́ alaafia ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn.
8 Òpópó ọ̀nà ṣófo, àwọn èrò kò rìn mọ́; wọ́n ń ba majẹmu jẹ́, wọn kò bìkítà fún ẹlẹ́rìí mọ́; wọ́n kò sì ka eniyan sí.
9 Ilẹ̀ ṣófo ó sì gbẹ, ìtìjú bá òkè Lẹbanoni, gbogbo ewéko orí rẹ̀ sì rẹ̀ dànù. Ṣaroni dàbí aṣálẹ̀, igi igbó Baṣani ati ti òkè Kamẹli sì wọ́wé.
10 OLUWA ní: “Ó yá tí n óo dìde, ó yá mi wàyí, n óo gbéra nílẹ̀. Àsìkò tó tí a óo gbé mi ga.
11 Èrò yín dàbí fùlùfúlù, gbogbo ìṣe yín dàbí pòpórò ọkà. Èémí mi yóo jó yín run bí iná.
12 Àwọn orílẹ̀-èdè yóo dàbí ìgbà tí a sun wọ́n, tí wọ́n di eérú, àní bí igi ẹ̀gún tí a gé lulẹ̀, tí a sì dáná sun.
13 Ẹ̀yin tí ẹ wà lókè réré, ẹ gbọ́ ohun tí mo ṣe; ẹ̀yin tí ẹ wà nítòsí, ẹ kíyèsí agbára mi.”
14 Ẹ̀rù ń ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tí ó wà ní Sioni; ìjayà mú àwọn ẹni tí kò mọ Ọlọrun. Ta ni ninu wa ló lè gbé inú iná ajónirun? Ta ni ninu wa ló lè gbé inú iná àjóòkú?
15 Ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ bá tọ́, tí ó sì ń sọ ọ̀rọ̀ òtítọ́, ẹni tí ó kórìíra èrè àjẹjù, tí ó kọ̀, tí kò gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí sí ọ̀rọ̀ àwọn tí ń gbèrò ati paniyan, tí ó sì di ojú rẹ̀ kí ó má baà rí nǹkan ibi.
16 Ibi ààbò ni yóo máa gbé, àpáta ńlá ni yóo jẹ́ ibi ààbò rẹ̀. Yóo máa rí oúnjẹ jẹ déédé, yóo sì máa rí omi mu lásìkò, lásìkò.
17 Ojú yín yóo rí ọba ninu ọlá ńlá rẹ̀; ẹ óo fojú yín rí ilẹ̀ tí ó lọ salalu.
18 Ẹ óo máa ronú ìnira tí ẹ ti ní pé: “Níbo ni akọ̀wé wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó orí wà? Níbo sì ni ẹni tí ń ka ilé ìṣọ́ wà?”
19 Ẹ kò ní rí àwọn aláfojúdi náà mọ́, àwọn tí wọn ń fọ èdè tí kò ní ìtumọ̀ si yín, tí wọn ń kólòlò ní èdè tí ẹ kò gbọ́.
20 Ẹ wo Sioni, ìlú tí a yà sọ́tọ̀ fún àjọ̀dún. Ẹ óo fi ojú rí Jerusalẹmu, ibùgbé alaafia, tí àgọ́ rẹ̀ kò ní ṣídìí, tí èèkàn tí a fi kàn án mọ́lẹ̀ kò ní hú laelae, bẹ́ẹ̀ ni okùn tí a fi so ó mọ́lẹ̀ kò ní já.
21 Ṣugbọn níbẹ̀ ni OLUWA, ninu ògo rẹ̀, yóo jẹ́ odò ńlá ati odò tí ń ṣàn fún wa; níbi tí ọkọ̀ ọlọ́pọ́n kò lè dé, ọkọ̀ ojú omi kò sì ní lè kọjá níbẹ̀.
22 Nítorí pé OLUWA ni onídàájọ́ wa, òun ni alákòóso wa; OLUWA ni ọba wa, òun ni yóo gbà wá là.
23 Okùn òpó-ọkọ̀ rẹ̀ ti tú, kò lè mú òpó-ọkọ̀ náà dáradára ní ipò rẹ̀ mọ́; kò sì lè gbé ìgbòkun dúró. A óo pín ọpọlọpọ ìkógun nígbà náà, kódà, àwọn arọ pàápàá yóo pín ninu rẹ̀.
24 Kò sí ará ìlú kan tí yóo sọ pé, “Ara mi kò yá.” A óo dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.
1 Ẹ súnmọ́ ibí, kí ẹ wá gbọ́, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, ẹ tẹ́tí sílẹ̀, gbogbo ẹ̀yin eniyan. Kí ilẹ̀ gbọ́ ati gbogbo ohun tí ó wà lórí rẹ̀, kí ayé tẹ́tí sílẹ̀ pẹlu gbogbo nǹkan tí ń ti inú rẹ̀ jáde.
2 Nítorí OLUWA ń bínú sí gbogbo orílẹ̀-èdè, inú rẹ̀ sì ń ru sí àwọn eniyan ibẹ̀. Ó ti fi wọ́n sílẹ̀ fún ìparun, ó sì ti fà wọ́n kalẹ̀ fún pípa.
3 A óo wọ́ òkú wọn jùnù, òkú wọn yóo máa rùn; ẹ̀jẹ̀ wọn yóo sì máa ṣàn lórí àwọn òkè.
4 Oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀ yóo gbọ̀n dànù a óo ká awọsanma bí ẹni ká ìwé. Oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀ yóo jábọ́ bí ewé tií rẹ̀ sílẹ̀ lára ìtàkùn àjàrà, àní, bí ewé tií wọ́ dànù lórí igi ọ̀pọ̀tọ́.
5 Nítorí mo ti rẹkẹ idà mi lókè ọ̀run, yóo sọ̀kalẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ àwọn ará Edomu; yóo sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn tí mo fẹ́ parun.
6 OLUWA ní idà kan tí a tì bọ inú ẹ̀jẹ̀, a rì í sinu ọ̀rá, pẹlu ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́ aguntan ati ti ewúrẹ́, ati ọ̀rá ara kíndìnrín àgbò. Nítorí pé OLUWA yóo rú ẹbọ ní Bosira, yóo sì pa ọpọlọpọ eniyan ní ilẹ̀ Edomu.
7 Àwọn mààlúù igbó yóo kú pẹlu wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù ati àwọn akọ mààlúù ńlá. Ilẹ̀ wọn yóo kún fún ẹ̀jẹ̀, ọ̀rá eniyan yóo sì mú kí ilẹ̀ wọn lẹ́tù lójú.
8 Nítorí OLUWA ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀ fún ẹ̀san, ó ti ya ọdún kan sọ́tọ̀ tí yóo gbèjà Sioni.
9 Àwọn odò ilẹ̀ Edomu yóo di ọ̀dà, erùpẹ̀ rẹ̀ yóo di imí ọjọ́; ilẹ̀ Edomu yóo di ọ̀dà tí ń jó bùlàbùlà.
10 Yóo máa jó tọ̀sán-tòru, kò ní kú, yóo máa rú èéfín sókè títí lae. Yóo di aṣálẹ̀ láti ìrandíran, ẹnikẹ́ni kò ní gbabẹ̀ kọjá mọ́ títí lae.
11 Àṣá ati òòrẹ̀ ni yóo fi ibẹ̀ ṣe ilé, òwìwí ati ẹyẹ kannakánná ni yóo máa gbé ibẹ̀. OLUWA yóo ta okùn ìdàrúdàpọ̀ lé e lórí, yóo sì na ọ̀pá ìdàrúdàpọ̀ lé àwọn ìjòyè rẹ̀ lórí.
12 “Kò sí Ilẹ̀ Ọba Mọ́” ni a óo máa pè é. Gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ yóo parẹ́.
13 Ẹ̀gún yóo hù ninu ààfin rẹ̀, ẹ̀gún òṣùṣú ati ẹ̀gún ọ̀gàn yóo hù ninu àwọn ìlú olódi rẹ̀. Wọn yóo di ibùgbé fún àwọn ọ̀fàfà ati ẹyẹ ògòǹgò,
14 àwọn ẹranko ìgbẹ́ ati ìkookò yóo jọ máa gbé ibẹ̀, àwọn ewúrẹ́ igbó yóo máa ké pe ara wọn. Iwin yóo rí ibi máa gbé, yóo sì rí ààyè máa sinmi níbẹ̀.
15 Òwìwí yóo pa ìtẹ́ sibẹ, tí yóo máa yé sí. Yóo pamọ, yóo ràdọ̀ bo àwọn ọmọ rẹ̀, yóo sì máa tọ́jú wọn níbẹ̀. Àwọn àṣá yóo péjọ sibẹ, olukuluku wọn, pẹlu ekeji rẹ̀.
16 Ẹ lọ wá inú ìwé OLUWA, kí ẹ ka ohun tí ó wà níbẹ̀. Kò sí ọ̀kan ninu àwọn wọnyi tí kò ní sí níbẹ̀, kò sí èyí tí kò ní ní ẹnìkejì. Nítorí OLUWA ni ó pàṣẹ bẹ́ẹ̀, ẹ̀mí rẹ̀ ni ó sì kó wọn jọ.
17 Ó ti ṣẹ́ gègé fún wọn, ó ti fi okùn wọ̀n ọ́n kalẹ̀ fún wọn. Àwọn ni wọn óo ni ín títí lae, wọn óo sì máa gbé ibẹ̀ láti ìrandíran.
1 Inú aṣálẹ̀ ati ilẹ̀ gbígbẹ yóo dùn, aṣálẹ̀ yóo yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, yóo rúwé, yóo sì tanná.
2 Nítòótọ́ yóo tanná bí òdòdó, yóo yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, yóo sì kọrin. Ògo Lẹbanoni yóo di tìrẹ ati iyì Kamẹli ati ti Ṣaroni. Wọn óo rí ògo OLUWA, wọn óo rí ọlá ńlá Ọlọrun wa.
3 Ẹ gbé ọwọ́ tí kò lágbára ró. Ẹ fún orúnkún tí kò lágbára ní okun.
4 Ẹ sọ fún àwọn tí àyà wọn ń já pé: “Ẹ ṣe ara gírí, ẹ má bẹ̀rù. Ẹ wò ó! Ọlọrun yín óo wá pẹlu ẹ̀san, ó ń bọ̀ wá gbẹ̀san gẹ́gẹ́ bí Ọlọrun; ó ń bọ̀ wá gbà yín là.”
5 Ojú afọ́jú yóo là nígbà náà, etí adití yóo sì ṣí;
6 arọ yóo máa fò bí ìgalà, odi yóo sì máa kọ orin ayọ̀. Nítorí odò ńlá yóo ṣàn jáde ninu aginjù àwọn odò kéékèèké yóo máa ṣàn ninu aṣálẹ̀.
7 Ilẹ̀ iyanrìn gbígbóná yóo di adágún omi ilẹ̀ gbígbẹ yóo di orísun omi, ibi tí ọ̀fàfà fi ṣe ilé tẹ́lẹ̀ yóo di àbàtà, èèsún ati ìyè yóo máa dàgbà níbẹ̀.
8 Òpópónà kan yóo wà níbẹ̀, a óo máa pè é ní Ọ̀nà Ìwà Mímọ́; nǹkan aláìmọ́ kan kò ní gba ibẹ̀ kọjá, àwọn aláìgbọ́n kò sì ní dẹ́ṣẹ̀ níbẹ̀.
9 Kò ní sí kinniun níbẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹranko burúkú kankan kò ní gba ibẹ̀. A kò ní rí wọn níbẹ̀, àwọn tí a ti rà pada ni yóo gba ibẹ̀.
10 Àwọn tí OLUWA rà pada yóo pada, wọn óo wá sí Sioni pẹlu orin, ayọ̀ ayérayé yóo kún inú wọn. Wọn óo rí ayọ̀ ati ìdùnnú gbà ìbànújẹ́ ati òṣé yóo sá kúrò níbẹ̀.
1 Ní ọdún kẹrinla tí Ọba Hesekaya jọba, Senakeribu, ọba Asiria gbógun ti gbogbo ìlú olódi Juda, ó sì kó wọn.
2 Ọba Asiria rán Rabuṣake (olórí ogun rẹ̀), pẹlu ọpọlọpọ ọmọ ogun; láti Lakiṣi sí ọba Hesekaya ní Jerusalẹmu. Nígbà tí wọn dé ibi tí omi tí ń ṣàn wọ ìlú láti orí òkè tí ó wà ní ọ̀nà pápá alágbàfọ̀, wọ́n dúró níbẹ̀.
3 Eliakimu, ọmọ Hilikaya tí ó jẹ́ alákòóso ààfin jáde lọ bá wọn pẹlu Ṣebina, akọ̀wé ilé ẹjọ́, ati Joa ọmọ Asafu, akọ̀wé ààfin.
4 Rabuṣake bá sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún Hesekaya pé ọba ńlá Asiria ní kí ló gbójú lé rí?
5 Ó ní ṣé Hesekaya rò pé ọ̀rọ̀ ẹnu ni ọgbọ́n ati agbára tí wọ́n fi ń jagun ni; àbí ta ló gbójú lé tí ó fi ń ṣàìgbọràn sí òun?
6 Ó ní Ijipti tí Hesekaya gbára lé dàbí kí eniyan fi ìyè ṣe ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀, ìyè tí yóo dá, tí yóo sì gún ẹnikẹ́ni tí ó bá gbára lé e lọ́wọ́. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ijipti jẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bá gbára lé e.
7 “Ó ní bí Hesekaya bá sì sọ fún òun pé, OLUWA Ọlọrun àwọn ni àwọn gbójú lé, òun óo bi í pé, ṣé kì í ṣe ojúbọ OLUWA náà ati àwọn pẹpẹ ìrúbọ rẹ̀ ni Hesekaya wó lulẹ̀ nígbà tí ó sọ fún àwọn ará Juda ati àwọn ará Jerusalẹmu pé, ẹyọ pẹpẹ kan ni kí wọ́n ti máa sin OLUWA?”
8 Rabuṣake ní, “Mo fẹ́ kí Hesekaya bá oluwa mi, ọba Asiria, ṣe pàṣípààrọ̀ kan, n óo fún un ní ẹgbaa ẹṣin bí ó bá lè rí eniyan tó tí ó lè gùn wọ́n.
9 Báwo ni ó ṣe lè lé ẹni tí ó kéré jù ninu àwọn olórí-ogun oluwa mi pada sẹ́yìn, nígbà tí ó jẹ́ pé Ijipti ni ó gbójú lé pé wọn óo fún un ní kẹ̀kẹ́ ogun ati àwọn ẹlẹ́ṣin?
10 Ẹ bi í pé, ṣé kò mọ̀ pé wíwá tí mo wá láti gbógun ti ìlú yìí ati láti pa á run kò ṣẹ̀yìn OLUWA? OLUWA ni ó sọ fún mi pé kí n lọ gbógun ti ilẹ̀ yìí, kí n sì pa á run.”
11 Nígbà náà ni Eliakimu ati Ṣebina ati Joa sọ fún Rabuṣake pé, “Jọ̀wọ́, èdè Aramaiki ni kí o fi bá wa sọ̀rọ̀, nítorí pé àwa náà gbọ́ Aramaiki. Má fi èdè Juda bá wa sọ̀rọ̀ kí àwọn ará wa tí ó wà lórí odi má baà gbọ́.”
12 Ṣugbọn Rabuṣake dá wọn lóhùn pé, “Ṣé ẹ rò pé ẹ̀yin ati oluwa yín nìkan ni oluwa mi rán mi pé kí n jíṣẹ́ yìí fún ni? Ṣé kò yẹ kí gbogbo àwọn eniyan tí wọ́n jókòó lórí odi ìlú yìí fetí wọn gbọ́ pé, ati àwọn ati ẹ̀yin, ẹ ti gbé, ẹ o máa jẹ ìgbọ̀nsẹ̀ ara yín, ẹ óo sì máa mu ìtọ̀ yín?”
13 Rabuṣake bá dìde dúró, ó sì kígbe ní èdè Juda, ó ní, “Ẹ gbọ́ ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria wí:
14 Ọba ní kí ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekaya tàn yín jẹ, nítorí kò ní le gbà yín là.
15 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekaya mú kí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, kí ó máa wí fún yín pé, ‘Dájúdájú OLUWA yóo gbà wá, ọba Asiria kò ní fi ogun kó ìlú yìí.’
16 “Ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ Hesekaya; nítorí ọba Asiria ní kí ẹ bá òun ṣe àdéhùn alaafia kí ẹ jáde tọ òun wá. Bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, olukuluku yín ni yóo máa jẹ èso àjàrà ati èso ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, olukuluku yín yóo sì máa mu omi ninu kànga rẹ̀;
17 títí òun óo fi wá mú yín lọ sí ilẹ̀ mìíràn tí ó dàbí ilẹ̀ yín, ilẹ̀ tí ó kún fún ọkà ati ọtí, tí oúnjẹ ati ọgbà àjàrà ti pọ̀.
18 Ẹ ṣọ́ra kí Hesekaya má baà fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣì yín lọ́nà, kí ó máa sọ pé, ‘OLUWA yóo gbà wá.’ Ṣé ọ̀kankan ninu àwọn oriṣa àwọn orílẹ̀-èdè yòókù ti gba ilẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ lọ́wọ́ Ọba Asiria rí?
19 Àwọn oriṣa Hamati ati Aripadi dà? Níbo ni àwọn oriṣa Sefafaimu wà? Ṣé wọn gba àwọn ará Samaria kalẹ̀ lọ́wọ́ mi?
20 Èwo ninu àwọn oriṣa ilẹ̀ wọnyi ni ó gba ilẹ̀ rẹ̀ kalẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí ẹ fi rò pé OLUWA yóo gba Jerusalẹmu kalẹ̀ lọ́wọ́ mi?”
21 Gbogbo wọn dákẹ́, kò sí ẹnìkan tí ó sọ nǹkankan nítorí ọba ti pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ dá a lóhùn.
22 Eliakimu, ọmọ Hilikaya tí ó jẹ́ alákòóso ààfin ati Ṣebina, akọ̀wé ilé ẹjọ́, ati Joa, ọmọ Asafu, akọ̀wé ààfin wá sọ́dọ̀ Hesekaya pẹlu àwọn ti aṣọ wọn tí wọ́n ti fàya láti fi ìbànújẹ́ wọn hàn, wọ́n sì sọ ohun tí Rabuṣake wí fún un.
1 Nígbà tí Hesekaya ọba gbọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì wọ inú ilé OLUWA lọ.
2 Ó rán Eliakimu tí ń ṣàkóso ààfin, ati Ṣebina akọ̀wé ilé ẹjọ́ ati àwọn àgbààgbà alufaa, wọ́n da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, wọ́n lọ sọ́dọ̀ wolii Aisaya, ọmọ Amosi.
3 Wọ́n jíṣẹ́ fún un, wọ́n ní, “Hesekaya ní kí á sọ fún ọ pé: ‘Ọjọ́ ìṣòro ni ọjọ́ òní, ọjọ́ ìyà, ati ọjọ́ ẹ̀sín. Ọmọ ń mú aboyún, ó dé orí ìkúnlẹ̀, ṣugbọn kò sí agbára láti bíi.
4 Ó ṣeéṣe kí OLUWA Ọlọrun rẹ ti gbọ́ iṣẹ́ tí ọba Asiria rán Rabuṣake, iranṣẹ rẹ̀, pé kí ó wá fi Ọlọrun alààyè ṣe ẹlẹ́yà, kí OLUWA Ọlọrun rẹ ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ lórí irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀! Nítorí náà gbé ohùn ẹ̀bẹ̀ sókè kí o gbadura fún àwọn eniyan tí ó kù.’ ”
5 Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Hesekaya ọba jíṣẹ́ fún Aisaya,
6 Aisaya dá wọn lóhùn pé, “Ẹ wí fún oluwa yín pé OLUWA ní: ‘Má bẹ̀rù nítorí ọ̀rọ̀ tí o gbọ́ tí iranṣẹ ọba Asiria sọ tí ó ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà.
7 Ìwọ máa wò ó, n óo fi ẹ̀mí kan sí inú rẹ̀, yóo gbọ́ ìròyìn èké kan, yóo sì pada lọ sí ilẹ̀ rẹ̀. Nígbà tí ó bá dé ilé n óo jẹ́ kí wọ́n fi idà pa á.’ ”
8 Rabuṣake gbọ́ pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi, nítorí náà, ó lọ bá a níbi tí ó ti ń bá àwọn ará Libina jagun.
9 Ibẹ̀ ni àwọn kan ti ròyìn fún ọba Asiria pé, Tirihaka ọba Etiopia ń bọ̀ wá gbógun tì í. Nígbà tí ó gbọ́, ó rán ikọ̀ lọ bá Hesekaya, ó ní:
10 “Ẹ sọ fún Hesekaya ọba Juda pé kí ó má jẹ́ kí Ọlọrun rẹ̀ tí ó gbójú lé ṣì í lọ́nà kí ó sọ pé ọba Asiria kò ní fi ogun kó Jerusalẹmu.
11 Ṣebí Hesekaya ti gbọ́ ohun tí àwọn ọba Asiria ṣe sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè, tí wọ́n pa wọ́n run patapata. Ṣé Hesekaya rò pé a óo gba òun là ni?
12 Ṣé àwọn oriṣa orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun gbà wọ́n sílẹ̀, àwọn orílẹ̀-èdè bíi Gosani ati Harani, Resefu ati àwọn ará Edẹni tí ń gbé Telasari?
13 Ọba Hamati dà? Ọba Aripadi ńkọ́? Níbo ni ọba ìlú Sefafaimu ati ọba Hena ati ọba Ifa wà?”
14 Hesekaya gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn ikọ̀ ọba Asiria, ó kà á. Nígbà tí ó kà á tán, ó gbéra, ó lọ sí ilé OLUWA, ó bá tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú OLUWA,
15 Hesekaya bá gbadura sí OLUWA, ó ní:
16 “Ìwọ OLUWA àwọn ọmọ-ogun, Ọlọrun Israẹli, ìwọ tí ìtẹ́ rẹ wà lórí àwọn Kerubu, ìwọ nìkan ni Ọlọrun gbogbo ìjọba ayé, ìwọ ni ó sì dá ọ̀run ati ayé.
17 Dẹtí sílẹ̀ OLUWA, kí o gbọ́. La ojú rẹ, OLUWA, kí o máa wo nǹkan. Gbọ́ irú iṣẹ́ tí Senakeribu rán tí ó ń fi ìwọ Ọlọrun alààyè ṣe ẹlẹ́yà.
18 Lóòótọ́ ni, OLUWA, pé àwọn ọba Asiria ti pa gbogbo orílẹ̀-èdè run tàwọn ti ilẹ̀ wọn,
19 ati pé wọ́n ju oriṣa wọn sinu iná, nítorí pé wọn kì í ṣe Ọlọrun. Iṣẹ́ ọwọ́ eniyan ni wọ́n, tí wọ́n fi igi ati òkúta ṣe, nítorí náà ni wọ́n ṣe lè pa wọ́n run.
20 Nisinsinyii, OLUWA Ọlọrun wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, kí gbogbo ìjọba ayé lè mọ̀ pé ìwọ nìkan ni OLUWA.”
21 Aisaya ọmọ Amosi bá ranṣẹ sí Hesekaya, pé OLUWA, Ọlọrun Israẹli ní, nítorí pé Hesekaya ti gbadura sí òun nípa Senakeribu ọba Asiria,
22 ohun tí OLUWA sọ nípa rẹ̀ ni pé: “Sioni bu ẹnu àtẹ́ lù ọ́, Senakeribu, ó fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà, Jerusalẹmu ń yọ ṣùtì sí ọ.
23 Ta ni ò ń sọ̀rọ̀ aṣa sí, tí ò ń fí ń ṣe ẹlẹ́yà? Ta ni ò ń ṣíjú wò pẹlu ìgbéraga? Ṣé Ẹni Mímọ́ Israẹli ni o ṣe irú èyí sí?
24 O rán àwọn iranṣẹ rẹ láti fi OLUWA ṣe ẹlẹ́yà, o ní, ‘Mo ti fi ọpọlọpọ kẹ̀kẹ́ ogun mi gun orí àwọn òkè gíga lọ, mo dé góńgó orí òkè Lẹbanoni. Mo ti gé àwọn igi kedari rẹ̀ tí ó ga jùlọ lulẹ̀, ati àwọn ààyò igi firi rẹ̀. Mo ti dé ibi tí ó ga jùlọ ní ilẹ̀ rẹ̀, ati igbó rẹ̀ tí ó dí jùlọ.
25 Mo gbẹ́ kànga mo sì mu omi ninu wọn. Mo ti fi ẹsẹ̀ mi tẹ gbogbo omi odò kéékèèké ilẹ̀ Ijipti ní àtẹ̀gbẹ.’
26 “Ṣé o kò tíì gbọ́ pé láti ìgbà pípẹ́, ni mo ti pinnu ohun tí mò ń mú ṣẹ nisinsinyii? Láti ayébáyé ni mo ti ṣètò rẹ̀, pé kí o wó ìlú olódi palẹ̀, kí ó di òkítì àlàpà.
27 Kí àwọn eniyan tí ń gbé inú wọn má ní agbára mọ́, kí wọ́n wà ninu ìdààmú ati ìpayà. Kí wọ́n dàbí ewé inú oko ati bíi koríko tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ hù bí koríko tí ó hù lórí òrùlé, tíí gbẹ kí ó tó dàgbà.
28 “Mo mọ ìjókòó rẹ. Mo mọ ìjáde ati ìwọlé rẹ, ati inú tí ò ń bá mi bí.
29 Nítorí pé ò ń bá mi bínú, mo sì ti gbọ́ nípa ìwà ìgbéraga rẹ, n óo sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní imú, n óo fi ìjánu bọ̀ ọ́ ni ẹnu, n óo sì dá ọ pada sí ọ̀nà tí o gbà wá.
30 “Ohun tí yóo jẹ́ àmì fún ọ nìyí Hesekaya: Ní ọdún yìí, ohun tí ó bá lalẹ̀ hù ni ẹ óo máa jẹ. Ní ọdún tí ń bọ̀ pẹlu, ohun tí ó bá lalẹ̀ hù ni ẹ óo máa jẹ bákan náà. Ní ọdún kẹta, ẹ gbin nǹkan ọ̀gbìn, kí ẹ sì kórè rẹ̀, ẹ ṣe ọgbà àjàrà kí ẹ sì máa jẹ èso inú rẹ̀.
31 Àwọn ọmọ Juda tí ó bá ṣẹ́kù yóo fi gbòǹgbò múlẹ̀, wọn óo sì so èso.
32 Àwọn eniyan yóo ṣẹ́kù tí yóo wá láti Jerusalẹmu àwọn tí wọn yóo sá àsálà yóo wá láti orí òkè Sioni. Ìtara OLUWA àwọn ọmọ ogun ni yóo ṣe èyí.
33 “Nítorí náà, ohun tí OLUWA wí nípa ọba Asiria ni pé, ‘Kò ní wọ inú ìlú yìí, kò sì ní ta ọfà sí i. Àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kò ní kó apata wọ inú rẹ̀. Wọn kò sì ní dó tì í.
34 Ọ̀nà tí ọba Asiria gbà wá ni yóo gbà pada lọ, kò ní fi ẹsẹ̀ kan inú ìlú yìí.
35 N óo dáàbò bo ìlú yìí, n óo sì gbà á sílẹ̀ nítorí tèmi ati nítorí Dafidi iranṣẹ mi.’ ”
36 Angẹli OLUWA bá lọ sí ibùdó àwọn ọmọ ogun Asiria, ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹsan-an ó lé ẹgbẹẹdọgbọn (185,000) ninu wọn. Nígbà tí wọn jí ní àfẹ̀mọ́júmọ́ òkú kún ilẹ̀ lọ kítikìti.
37 Senakeribu ọba Asiria bá pada sílé, ó ń lọ gbé ìlú Ninefe.
38 Ní ọjọ́ kan, ó lọ bọ Nisiroku, oriṣa rẹ̀, àwọn meji ninu àwọn ọmọ rẹ̀: Adirameleki ati Ṣareseri, sì fi idà gún un pa, wọ́n bá sá lọ sí ilẹ̀ Ararati. Esaradoni ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.
1 Ní àkókò náà, Hesekaya ṣàìsàn, àìsàn náà pọ̀; ó fẹ́rẹ̀ kú. Aisaya wolii, ọmọ Amosi tọ̀ ọ́ wá ní ọjọ́ kan, ó wí fún un pé: “OLUWA ní kí n sọ fún ọ pé kí o ṣe ètò ilé rẹ, nítorí pé o óo kú ni, o kò ní yè.”
2 Hesekaya bá kọjú sí ògiri, ó gbadura sí OLUWA,
3 ó ní, “OLUWA, dákun, mo bẹ̀ ọ́ ni, ranti bí mo ti ṣe fi tọkàntọkàn rìn níwájú rẹ pẹlu òtítọ́ inú, tí mo sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ.” Hesekaya bá sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn.
4 OLUWA bá sọ fún Aisaya pé
5 kí ó lọ sọ fún Hesekaya pé, òun, OLUWA Ọlọrun Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti gbọ́ adura rẹ̀. Oun ti rí omijé rẹ̀, òun óo sì fi ọdún mẹẹdogun kún ọjọ́ ayé rẹ̀.
6 OLUWA ní òun óo gba Hesekaya lọ́wọ́ ọba Asiria, òun óo gbèjà ìlú Jerusalẹmu, òun óo sì dáàbò bò ó. Aisaya bá sọ fún Hesekaya pé kí wọn bá a wá èso ọ̀pọ̀tọ́ kí wọn lọ̀ ọ́, kí wọn fi lé ojú oówo tí ó mú un, kí ó lè gbádùn. Hesekaya bá bèèrè pé, kí ni àmì tí òun óo fi mọ̀ pé òun óo tún fi ẹsẹ̀ òun tẹ ilé Olúwa?"
7 Aisaya ní, àmì tí OLUWA fún Hesekaya tí yóo mú kí ó dá a lójú pé òun OLUWA yóo ṣe ohun tí òun ṣèlérí nìyí:
8 Òun óo mú kí òjìji oòrùn ìrọ̀lẹ́ pada sẹ́yìn ní àtẹ̀gùn mẹ́wàá lórí àtẹ̀gùn Ahasi. Oòrùn bá yí pada nítòótọ́, òjìji sì pada sẹ́yìn ní àtẹ̀gùn mẹ́wàá tí ó ti sọ tẹ́lẹ̀.
9 Orin tí Hesekaya ọba Juda kọ sílẹ̀ nígbà tí ó ṣàìsàn tí Ọlọrun sì wò ó sàn nìyí:
10 Mo ti rò pé n óo kú lọ́jọ́ àìpé, ati pé a óo sé mi mọ́ inú ibojì, níbẹ̀ ni n óo sì ti lo ìyókù ọjọ́ ayé mi.
11 Mo rò pé n kò ní tún fojú kan OLUWA mọ́ ní ilẹ̀ alààyè, ati pé n kò ní sí láàyè mọ́ láti tún fi ojú mi kan ẹnikẹ́ni.
12 A tú àgọ́ mi palẹ̀ bí àgọ́ darandaran, a sì ká a lọ kúrò lọ́dọ̀ mi. Mo ká ayé mi bí aṣọ tí wọn ń hun. Ó sì gé mi kúrò bí aṣọ tí wọ́n gé kúrò lórí òfì. Mo ti kọ́ rò pé tọ̀sán-tòru ni ìwọ OLUWA ń fi òpin sí ayé mi.
13 Mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́ títí ilẹ̀ fi mọ́ ó fọ́ gbogbo egungun mi bí kinniun ti máa ń fọ́ egungun. Tọ̀sán-tòru mo rò pé Ọlọrun ń fi òpin sí ayé mi ni.
14 Ọkàn mi ń ṣe hílàhílo bí ẹyẹ aláàpáǹdẹ̀dẹ̀ ati ẹyẹ àkọ̀, mò ń ké igbe arò bí àdàbà. Mo wòkè títí ojú ń ro mí, ara ń ní mí, OLUWA, nítorí náà ṣe ààbò mi.
15 Ṣugbọn kí ni mo lè sọ? Nítorí pé ó ti bá mi sọ̀rọ̀, òun fúnrarẹ̀ ni ó sì ṣe é Oorun kò kùn mí nítorí pé ọkàn mi bàjẹ́.
16 OLUWA, nǹkan wọnyi ni ó mú eniyan wà láàyè, ninu gbogbo rẹ̀ èmi náà yóo wà láàyè. Áà, jọ̀wọ́ wò mí sàn, kí o mú mi wà láàyè.
17 Nítorí ìlera mi ni mo ṣe ní ìbànújẹ́ lọpọlọpọ; ìwọ ni o dì mí mú, tí n kò fi jìn sinu kòtò ìparun, nítorí o ti sọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi di ohun ìgbàgbé.
18 Ibojì kò lè dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ikú kò lè yìn ọ́; kò sí ìrètí mọ́ fún àwọn tí wọ́n ti lọ sinu isà òkú, wọn kò lè gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ mọ́.
19 Alààyè, àní alààyè, ni ó lè máa yìn ọ́ bí mo ti yìn ọ́ lónìí. Baba a máa kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀, nípa òdodo rẹ.
20 OLUWA yóo gbà mí là, a óo fi àwọn ohun èlò orin olókùn kọrin ninu ilé OLUWA, ní gbogbo ọjọ́ ayé wa.
1 Ní àkókò náà Merodaki Baladani ọmọ Baladani, ọba Babiloni, fi ìwé ati ẹ̀bùn rán àwọn ikọ̀ kan sí Hesekaya, nítorí ó gbọ́ pé ara rẹ̀ kò ti dá tẹ́lẹ̀ ṣugbọn ara rẹ̀ ti wá le.
2 Hesekaya gbà wọ́n lálejò, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà ninu ilé ìṣúra rẹ̀ hàn wọ́n, fadaka ati wúrà, àwọn nǹkan olóòórùn dídùn ati òróró olówó iyebíye, ilé ìkó nǹkan ìjà ogun sí, ati gbogbo nǹkan tí ó wà ninu ilé ìṣúra. Kò sí nǹkan tí ó wà ní ìpamọ́ ní ààfin Hesekaya ní ilé rẹ̀ tí kò fihàn wọ́n.
3 Lẹ́yìn náà Aisaya wolii tọ Hesekaya ọba lọ, ó bi í pé, “Kí ni àwọn ọkunrin wọnyi wí, láti ibo ni wọ́n sì ti wá sọ́dọ̀ rẹ?” Hesekaya dáhùn, ó ní, “Láti ilẹ̀ òkèèrè, ní Babiloni ni wọ́n ti wá.”
4 Aisaya tún bi í pé, “Kí ni wọ́n rí láàfin rẹ?” Hesekaya dáhùn, ó ní, “Gbogbo ohun tó wà láàfin ni wọ́n rí. Kò sí ohun tí ó wà ní ilé ìṣúra mi tí n kò fihàn wọ́n.”
5 Aisaya bá sọ fún Hesekaya, pé, “Gbọ́ ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun wí:
6 Ó ní, ‘Ọjọ́ ń bọ̀ tí a óo ru gbogbo ohun tí ó wà láàfin rẹ lọ sí Babiloni, ati gbogbo ìṣúra tí àwọn baba ńlá rẹ ti kó jọ títí di òní. Kò ní ku nǹkankan.’ OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.
7 ‘A óo kó ninu àwọn ọmọ bíbí inú rẹ lọ, a óo sì fi wọ́n ṣe ìwẹ̀fà láàfin ọba Babiloni.’ ”
8 Hesekaya dá Aisaya lóhùn, ó ní, “Ohun rere ni OLUWA sọ.” Ó sọ bẹ́ẹ̀ nítorí ó rò pé alaafia ati ìfọ̀kànbalẹ̀ yóo wà ní àkókò tòun.
1 Ọlọrun yín ní, “Ẹ tù wọ́n ninu, ẹ tu àwọn eniyan mi ninu.
2 Ẹ bá Jerusalẹmu sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ ẹ ké sí i pé, ogun jíjà rẹ̀ ti parí, a ti dárí àìṣedéédé rẹ̀ jì í. OLUWA ti jẹ ẹ́ níyà ní ìlọ́po meji nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
3 Ẹ gbọ́ ohùn akéde kan tí ń wí pé, “Ẹ tún ọ̀nà OLUWA ṣe ninu aginjù, ẹ la òpópónà títọ́ fún Ọlọrun wa ninu aṣálẹ̀.
4 Gbogbo àfonífojì ni a óo ru sókè, a óo sì sọ àwọn òkè ńlá ati òkè kéékèèké di pẹ̀tẹ́lẹ̀: Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ́ ni yóo di títọ́, ọ̀nà gbágun-gbàgun yóo sì di títẹ́jú.
5 Ògo OLUWA yóo farahàn, gbogbo eniyan yóo sì jọ fojú rí i. OLUWA ni ó fi ẹnu ara rẹ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
6 Mo gbọ́ ohùn kan tí ń wí pé, “Kígbe!” Mo bá bèèrè pé, “Igbe kí ni kí n ké?” Ó ní, “Kígbe pé, koríko ṣá ni gbogbo eniyan, gbogbo ẹwà sì dàbí òdòdó inú pápá.
7 Koríko a máa rọ, òdòdó a sì máa rẹ̀ nígbà tí OLUWA bá fẹ́ afẹ́fẹ́ lù ú. Dájúdájú koríko ni eniyan.
8 Koríko a máa rọ, òdòdó a sì máa rẹ̀; ṣugbọn ọ̀rọ̀ Ọlọrun wa dúró títí lae.”
9 Gun orí òkè gíga lọ, ìwọ Sioni, kí o máa kéde ìyìn rere. Gbé ohùn rẹ sókè pẹlu agbára Jerusalẹmu, ìwọ tí ò ń kéde ìyìn rere ké sókè má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú Juda pé, “Ẹ wo Ọlọrun yín.”
10 Ẹ wò ó! OLUWA Ọlọrun ń bọ̀ pẹlu agbára ipá rẹ̀ ni yóo fi máa ṣe àkóso. Ẹ wò ó! Èrè rẹ̀ ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ̀san rẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.
11 Yóo bọ́ agbo ẹran bí olùṣọ́-aguntan. Yóo kó àwọn ọ̀dọ́ aguntan jọ sí apá rẹ̀, yóo gbé wọn mọ́ àyà rẹ̀. Yóo sì máa fi sùúrù da àwọn tí wọn lọ́mọ lẹ́yìn láàrin wọn.
12 Ta ló lè fi kòtò ọwọ́ wọn omi òkun? Ta ló lè fìka wọn ojú ọ̀run, Kí ó kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé sinu òṣùnwọ̀n? Ta ló lè gbé àwọn òkè ńlá ati àwọn kéékèèké sórí ìwọ̀n?
13 Ta ló darí Ẹ̀mí OLUWA, ta ló sì tọ́ ọ sọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 Ọwọ́ ta ni OLUWA ti gba ìmọ̀ràn tí ó fi ní òye, ta ló kọ́ ọ bí wọ́n ṣe ń dájọ́ ẹ̀tọ́, tí ó kọ́ ọ ní ìmọ̀, tí ó sì fi ọ̀nà òye hàn án?
15 Wò ó, àwọn orílẹ̀-èdè dàbí ìkán omi kan ninu garawa omi, ati bí ẹyọ eruku kan lórí òṣùnwọ̀n. Ẹ wò ó, ó mú àwọn erékùṣù lọ́wọ́ bí àtíkè.
16 Gbogbo igi igbó Lẹbanoni kò tó fún iná ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹranko ibẹ̀ kò tó fún ẹbọ sísun.
17 Gbogbo orílẹ̀-èdè kò tó nǹkan níwájú rẹ̀, wọn kò jámọ́ nǹkan lójú rẹ̀, òfo ni wọ́n.
18 Ta ni ẹ lè fi Ọlọrun wé, tabi kí ni ẹ lè fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 Ṣé oriṣa ni! Tí oníṣẹ́ ọwọ́ ṣe; tí alágbẹ̀dẹ wúrà yọ́ wúrà bò tí ó sì fi fadaka ṣe ẹ̀wọ̀n fún?
20 Ẹni tí ó bá talaka, tí kò lágbára nǹkan ìrúbọ, a wá igi tí kò lè rà, tí kò sì lè ju; a wá agbẹ́gilére tí ó mọṣẹ́, láti bá a gbẹ́ ère tí kò lè paradà.
21 Ṣé ẹ kò tíì mọ̀? Ẹ kò sì tíì gbọ́? Ṣé wọn kò sọ fun yín láti ìbẹ̀rẹ̀, kò sì ye yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, pé:
22 Òun ni ó jókòó lókè àyíká ayé, àwọn eniyan inú rẹ̀ sì dàbí tata lójú rẹ̀. Òun ni ó ta awọsanma bí aṣọ títa, ó sì ta á bí àgọ́, ó ń gbébẹ̀.
23 Ẹni tí ó sọ àwọn ọba di ẹni ilẹ̀, ó sọ àwọn olóyè ayé di asán.
24 Wọ́n fẹ́rẹ̀ má ì tíì gbìn wọ́n, wọ́n fẹ́rẹ̀ má ì tíì ta gbòǹgbò wọlẹ̀; nígbà tí ó fẹ́ afẹ́fẹ́ lù wọ́n, tí wọ́n fi rọ bí ewéko, tí ìjì sì gbé wọn lọ bí àgékù koríko.
25 Ta ni ẹ óo wá fi mí wé, tí n óo sì dàbí rẹ̀? Èmi Ẹni Mímọ́ ni mo bèèrè bẹ́ẹ̀.
26 Ẹ gbójú sókè kí ẹ wo ojú ọ̀run, ta ni ó dá àwọn nǹkan tí ẹ rí wọnyi? Ẹni tí ó kó àwọn ìràwọ̀ sójú ọ̀run bí ọmọ ogun, tí ó ń pè wọ́n jáde lọ́kọ̀ọ̀kan, tí ó sì mọ olukuluku mọ́ orúkọ rẹ̀. Nítorí bí ipá rẹ̀ ti tó, ati bí agbára rẹ̀ ti pọ̀ tó, ẹyọ ọ̀kan ninu wọn kò di àwátì.
27 Kí ló dé, Jakọbu, tí o fi ń rojọ́? Kí ló ṣe ọ́, Israẹli, tí o fi ń sọ pé, “OLUWA kò mọ ohun tí ń ṣe mí, Ọlọrun kò sì bìkítà nípa ẹ̀tọ́ mi.”
28 Ṣé o kò tíì mọ̀, o kò sì tíì gbọ́ pé Ọlọrun ayérayé ni OLUWA, Ẹlẹ́dàá gbogbo ayé. Kì í rẹ̀ ẹ́, bẹ́ẹ̀ ni agara kì í dá a. Àwámárìídìí ni òye rẹ̀.
29 A máa fún aláàárẹ̀ ní okun. A sì máa fún ẹni tí kò lágbára ní agbára.
30 Yóo rẹ àwọn ọ̀dọ́ pàápàá, agara óo sì dá wọn, àwọn ọdọmọkunrin yóo tilẹ̀ ṣubú lulẹ̀ patapata.
31 Ṣugbọn àwọn tí ó bá dúró de OLUWA yóo máa gba agbára kún agbára. Wọn óo máa fi ìyẹ́ fò lọ sókè bí ẹyẹ idì. Wọn óo máa sáré, agara kò ní dá wọn; wọn óo máa rìn, kò sì ní rẹ̀ wọ́n.
1 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin erékùṣù, kí àwọn eniyan gba agbára kún agbára wọn, kí wọ́n súnmọ́ ìtòsí, kí wọ́n sọ tẹnu wọn, ẹ jẹ́ kí á pàdé ní ilé ẹjọ́.
2 “Ta ló gbé ẹnìkan dìde ní ìhà ìlà oòrùn? Tí ó ń ṣẹgun ní ibikíbi tí ó bá fẹsẹ̀ tẹ̀? Ta ló fi àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ tí ó fi lè tẹ àwọn ọba mọ́lẹ̀? Idà rẹ̀ gé wọn bí eruku, ọfà rẹ̀ sì tú wọn ká bí àgékù koríko.
3 A máa lépa wọn, a sì máa kọjá wọn láìléwu, ní ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò tẹ̀ rí.
4 Ta ló ṣe èyí? Iṣẹ́ ọwọ́ ta sì ni? Tí ó pe ìran dé ìran láti ìbẹ̀rẹ̀? Èmi OLUWA ni, ẹni àkọ́kọ́ ati ẹni ìkẹyìn.
5 “Àwọn erékùṣù rí i, ẹ̀rù bà wọ́n, gbogbo òpin ayé gbọ̀n rìrì wọ́n ti súnmọ́ tòsí, wọ́n ti dé.
6 Olukuluku ń ran ẹnìkejì rẹ̀ lọ́wọ́, ó ń sọ fún arakunrin rẹ̀ pé, ‘Ṣara gírí.’
7 Agbẹ́gilére ń gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú ẹni tí ń fi òòlù lu irin ń kí ẹni tí ń dán irin tí wọ́n ti rọ, Ó ń wí pé: ‘Òjé tí a fi jó o dára.’ Wọ́n kàn án ní ìṣó, ó le dáradára, kò le mì.
8 “Ìwọ ní tìrẹ, Israẹli iranṣẹ mi, Jakọbu, ìwọ tí mo ti yàn, ọmọ bíbí inú Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi.
9 Ìwọ tí mo mú wá láti òpin ayé, tí mo pè láti ìkangun ayé tí ó jìnnà jùlọ, mo wí fún ọ pé, ‘Iranṣẹ mi ni ọ́, mo ti yàn ọ́, n kò ní ta ọ́ nù.’
10 Má bẹ̀rù, nítorí mo wà pẹlu rẹ, má fòyà, nítorí èmi ni Ọlọrun rẹ. N óo fún ọ ní agbára, n óo sì ràn ọ́ lọ́wọ́; ọwọ́ ọ̀tún mi, ọwọ́ ìṣẹ́gun, ni n óo fi gbé ọ ró.
11 “Gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ pa ọ́ run ni n óo dójú tì, wọn óo sì dààmú. Àwọn tí ń bá ọ jà yóo di asán, wọn óo sì ṣègbé.
12 O óo wá àwọn tí ń bá ọ jà tì, o kò ní rí wọn. Àwọn tí ó gbógun tì ọ́ yóo di òfo patapata.
13 Nítorí èmi OLUWA Ọlọrun rẹ, ti di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú, èmi ni mo sọ fún ọ pé kí o má bẹ̀rù, n óo ràn ọ́ lọ́wọ́.”
14 Ẹ má bẹ̀rù, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, bí ẹ tilẹ̀ dàbí kòkòrò lásán, ẹ̀yin ọmọ Israẹli, OLUWA ní òun óo ràn yín lọ́wọ́. Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà yín.
15 Ó ní, “N óo ṣe yín bí ohun èlò ìpakà titun, tí ó mú, tí ó sì ní eyín, ẹ óo tẹ àwọn òkè ńlá mọ́lẹ̀, ẹ óo rún wọn wómúwómú; ẹ óo sì sọ àwọn òkè kéékèèké di fùlùfúlù.
16 Ẹ óo fẹ́ wọn bí ọkà, atẹ́gùn yóo gbé wọn lọ, ìjì yóo sì fọ́n wọn ká. Ẹ̀yin óo yọ̀ ninu OLUWA ẹ óo sì ṣògo ninu Ẹni Mímọ́ Israẹli.
17 “Nígbà tí àwọn talaka ati àwọn aláìní bá ń wá omi, tí omi kò sí, tí òùngbẹ ń gbẹ wọ́n, tí ọ̀nà ọ̀fun wọn gbẹ, èmi OLUWA yóo dá wọn lóhùn, èmi Ọlọrun Israẹli kò ní fi wọ́n sílẹ̀.
18 N óo ṣí odò lórí àwọn òkè, ati orísun láàrin àwọn àfonífojì; n óo sọ aṣálẹ̀ di adágún odò, ilẹ̀ gbígbẹ yóo sì di orísun omi.
19 N óo gbin igi kedari sinu aṣálẹ̀, pẹlu igi akasia ati igi mitili ati igi olifi. N óo gbin igi sipirẹsi sinu aṣálẹ̀, n óo gbin igi firi ati pine papọ̀.
20 Kí àwọn eniyan lè rí i, kí wọn sì mọ̀, kí wọ́n rò ó wò, kí òye lè yé wọn papọ̀, pé ọwọ́ OLUWA ni ó ṣe èyí, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ṣẹ̀dá rẹ̀.”
21 OLUWA, Ọba Jakọbu, ní: “Ẹ̀yin oriṣa àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ ro ẹjọ́ yín, kí ẹ mú ẹ̀rí tí ó dájú wá lórí ohun tí ẹ bá ní sọ.
22 Ẹ mú wọn wá, kí ẹ sì sọ ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ fún wa; kí ẹ sọ àwọn ohun àtijọ́ fún wa. Kí á lè gbé wọn yẹ̀wò; kí á lè mọ àyọrísí wọn, tabi kí ẹ sọ àwọn ohun tí ń bọ̀ wá ṣẹlẹ̀ fún wa.”
23 OLUWA ní, “Ẹ sọ ohun tí ń bọ̀ lẹ́yìn ọ̀la fún wa, kí á lè mọ̀ pé oriṣa ni yín; ẹ ṣe nǹkan rere tabi nǹkan burúkú kan, kí á rí i, kí ẹ̀rù sì bà wá.
24 Ẹ wò ó! Òfo ni yín, òfo sì ni iṣẹ́ ọwọ́ yín, ẹni ìríra ni ẹni tí ó bá yàn yín.
25 Mo ti gbé ẹnìkan dìde láti ìhà àríwá, ó sì ti dé. Láti ìlà oòrùn ni yóo ti pe orúkọ mi; yóo máa gún àwọn ọba mọ́lẹ̀ bì ìgbà tí wọ́n gún nǹkan ninu odó, àní, bí ìgbà tí amọ̀kòkò bá ń gún amọ̀.
26 Ta ló kéde rẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, kí á lè mọ̀, ta ló sọ nípa rẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ kí á lè sọ pé, ‘Olóòótọ́ ni?’ Kò sí ẹni tí ó sọ ọ́, kò sí ẹni tí ó kéde rẹ̀; ẹnìkankan kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
27 Èmi OLUWA ni mo ti kọ́kọ́ sọ fún Sioni, tí mo sì ròyìn ayọ̀ náà fún Jerusalẹmu.
28 Nígbà tí mo wo ààrin àwọn wọnyi, kò sí olùdámọ̀ràn kan, tí ó lè dá mi lóhùn nígbà tí mo bá ní ìbéèrè.
29 Wò ó! Ìtànjẹ lásán ni gbogbo wọn, òfo ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn: Ẹ̀fúùfù lásán ni àwọn ère tí wọ́n gbẹ́.”
1 OLUWA ní, “Wo iranṣẹ mi, ẹni tí mo gbéró, àyànfẹ́ mi, ẹni tí inú mi dùn sí. Mo ti jẹ́ kí ẹ̀mí mi bà lé e, yóo máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́ fún àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Kò ní kígbe, kò sì ní pariwo, kò ní jẹ́ kí á gbọ́ ohùn rẹ̀ ní ìta gbangba.
3 Kò ní ṣẹ́ ọ̀pá ìyè tí ó tẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ní pa iná fìtílà tí ń jò bẹ́lúbẹ́lú, yóo fi òtítọ́ dá ẹjọ́.
4 Kò ní kùnà, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn rẹ̀ kò ní rẹ̀wẹ̀sì, títí yóo fi fìdí ìdájọ́ òdodo múlẹ̀ láyé. Àwọn erékùṣù ń retí òfin rẹ̀.”
5 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA Ọlọrun sọ; ẹni tí ó dá ojú ọ̀run tí ó sì ta á bí aṣọ, tí ó tẹ ayé, ati àwọn ohun tí ń hù jáde láti inú rẹ̀; ẹni tí ó fi èémí sinu àwọn eniyan tí ń gbé orí ilẹ̀; tí ó sì fi ẹ̀mí fún àwọn tí ó ń rìn lórí rẹ̀.
6 Ó ní, “Èmi ni OLUWA, mo ti pè ọ́ ninu òdodo, mo ti di ọwọ́ rẹ mú, mo sì pa ọ́ mọ́. Mo ti fi ọ́ ṣe majẹmu fún aráyé, mo sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè;
7 kí o lè la ojú àwọn afọ́jú, kí o lè yọ àwọn ẹlẹ́wọ̀n kúrò ni àhámọ́, kí o lè yọ àwọn tí ó jókòó ninu òkùnkùn kúrò ní ọgbà ẹ̀wọ̀n.
8 “Èmi ni OLUWA, bẹ́ẹ̀ ni orúkọ mi; n kò ní fi ògo mi fún ẹlòmíràn, n kò sì ní fi ìyìn mi fún ère.
9 Wò ó! Àwọn nǹkan àtijọ́ ti kọjá, àwọn nǹkan tuntun ni mò ń kéde nisinsinyii. Kí wọn tó yọjú jáde rárá, ni mo ti sọ fún ọ nípa wọn.”
10 Ẹ kọ orin tuntun sí OLUWA; ẹ kọ orin ìyìn rẹ̀ láti òpin ayé. Ẹ̀yin èrò inú ọkọ̀ lójú agbami òkun, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu omi òkun; ati àwọn erékùṣù ati àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Kí aṣálẹ̀ ati àwọn ìlú inú rẹ̀ kọ orin ìyìn sókè, ati àwọn abúlé agbègbè Kedari; kí àwọn ará ìlú Sela kọrin ayọ̀, kí wọn máa kọrin lórí àwọn òkè.
12 Kí wọn fi ògo fún OLUWA, kí wọn kéde ìyìn rẹ̀ ní àwọn erékùṣù.
13 OLUWA yọ jáde lọ bí alágbára ọkunrin, ó ru ibinu rẹ̀ sókè bí ọkunrin ogun, ó kígbe, ó sì bú ramúramù. Ó fihàn pé alágbára ni òun níwájú àwọn ọ̀tá rẹ̀. OLUWA ní:
14 “Ó ti pẹ́ tí mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo mára dúró. Ṣugbọn nisinsinyii, n óo kígbe, bí obinrin tí ń rọbí lọ́wọ́. N óo máa mí túpetúpe, n óo máa mí hẹlẹhẹlẹ.
15 N óo sọ àwọn òkè gíga ati àwọn kéékèèké di ilẹ̀, n óo mú kí gbogbo ewéko orí wọn gbẹ; n óo sọ àwọn odò di erékùṣù, n óo sì mú kí àwọn adágún omi gbẹ.
16 “N óo darí àwọn afọ́jú, n óo mú wọn gba ọ̀nà tí wọn kò mọ̀ rí, n óo tọ́ wọn sọ́nà, ní ọ̀nà tí wọn kò mọ̀ rí. N óo sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn, n óo sì sọ àwọn ibi tí ó rí pálapàla di títẹ́jú. N óo ṣe àwọn nǹkan, n kò sì ní kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
17 A óo ká àwọn tí ó gbójú lé ère lọ́wọ́ kò, ojú yóo sì tì wọ́n patapata àwọn tí ń wí fún ère gbígbẹ́ pé: ‘Ẹ̀yin ni Ọlọrun wa.’ ” OLUWA ní:
18 “Gbọ́, ìwọ adití, sì wò ó, ìwọ afọ́jú, kí o lè ríran.
19 Ta ni afọ́jú, bíkòṣe iranṣẹ mi? Ta sì ni adití, bíkòṣe ẹni tí mo rán níṣẹ́? Ta ni ó fọ́jú tó ẹni tí mo yà sọ́tọ̀, tabi ta ni ojú rẹ̀ fọ́ tó ti iranṣẹ OLUWA?
20 Ó ń wo ọpọlọpọ nǹkan, ṣugbọn kò ṣe akiyesi wọn. Etí rẹ̀ là sílẹ̀, ṣugbọn kò gbọ́ràn.”
21 Ó wu OLUWA láti gbé òfin rẹ̀ ga ati láti ṣe é lógo nítorí òdodo rẹ̀.
22 Ṣugbọn a ti ja àwọn eniyan wọnyi lólè, a sì ti kó wọn lẹ́rù, a ti sé gbogbo wọn mọ́ inú ihò ilẹ̀, a sì ti fi wọ́n pamọ́ sinu ọgbà ẹ̀wọ̀n. A fogun kó wọn, láìsí ẹni tí yóo gbà wọ́n sílẹ̀, a kó wọn lẹ́rú, láìsí ẹnikẹ́ni tí yóo sọ pé: “Ẹ dá wọn pada.”
23 Èwo ninu yín ló fetí sí èyí, tabi tí yóo farabalẹ̀ gbọ́ nítorí ẹ̀yìn ọ̀la?
24 Ta ló fa Jakọbu lé akónilẹ́rù lọ́wọ́, ta ló sì fa Israẹli lé àwọn ọlọ́ṣà lọ́wọ́? Ṣebí OLUWA tí a ti ṣẹ̀ ni, ẹni tí wọ́n kọ̀, tí wọn kò rìn ní ọ̀nà rẹ̀; tí wọn kò sì pa òfin rẹ̀ mọ́.
25 Nítorí náà ó jẹ́ kí wọ́n rí ibinu òun, ó sì fi agbára ogun rẹ̀ hàn wọ́n. Ó tanná ràn án lọ́tùn-ún lósì, sibẹ kò yé e; iná jó o, sibẹsibẹ kò fi ṣe àríkọ́gbọ́n.
1 Ṣugbọn nisinsinyii, Jakọbu, gbọ́ nǹkan tí OLUWA ẹlẹ́dàá rẹ wí, Israẹli, gbọ́ ohun tí ẹni tí ó dá ọ sọ. Ó ní, “Má bẹ̀rù, nítorí mo ti rà ọ́ pada; mo ti pè ọ́ ní orúkọ rẹ, èmi ni mo ni ọ́.
2 Nígbà tí o bá ń la ibú omi kọjá, n óo wà pẹlu rẹ; nígbà tí o bá la odò ńlá kọjá, kò ní bò ọ́ mọ́lẹ̀, nígbà tí o bá ń kọjá ninu iná, kò ní jó ọ. Ahọ́n iná kò ní jó ọ run.
3 Nítorí èmi ni OLUWA Ọlọrun rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, Olùgbàlà rẹ. Mo fi Ijipti, lélẹ̀, láti rà ọ́ pada, mo sì fi Etiopia ati Seba lélẹ̀ mo ti fi ṣe pàṣípààrọ̀ rẹ.
4 Nítorí pé o ṣọ̀wọ́n lójú mi, o níyì, mo sì fẹ́ràn rẹ, mo fi àwọn eniyan rọ́pò rẹ; mo sì fi ẹ̀mí àwọn orílẹ̀-èdè dípò ẹ̀mí rẹ.
5 Má bẹ̀rù nítorí mo wà pẹlu rẹ, n óo kó àwọn ọmọ rẹ wá láti ìlà oòrùn, n óo sì ko yín jọ láti ìwọ̀ oòrùn.
6 N óo pàṣẹ fún ìhà àríwá pé, ‘Dá wọn sílẹ̀.’ N óo sọ fún ìhà gúsù pé, ‘O kò gbọdọ̀ dá wọn dúró.’ Kó àwọn ọmọ mi ọkunrin wá láti òkèèrè, sì kó àwọn ọmọ mi obinrin wá láti òpin ayé,
7 gbogbo àwọn tí à ń fi orúkọ mi pè, àwọn tí mo dá fún ògo mi, àwọn tí mo fi ọwọ́ mi ṣẹ̀dá wọn.”
8 Ẹ mú àwọn eniyan mi jáde, àwọn tí wọ́n ní ojú, ṣugbọn tí ojú wọn ti fọ́, wọ́n ní etí, ṣugbọn etí wọn ti di.
9 Jẹ́ kí gbogbo orílẹ̀-èdè péjọ, kí àwọn eniyan àgbáyé parapọ̀. Èwo ninu wọn ni ó lè kéde irú àsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó lè fi àwọn ohun àtijọ́ hàn wá; kí wọn pe ẹlẹ́rìí wọn wá, kí á lè mọ̀ pé ẹjọ́ wọn tọ́, kí àwọn ẹlòmíràn lè gbọ́, kì wọn sì jẹ́rìí pé, “Òtítọ́ ni.”
10 OLUWA ní, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi, ẹ̀yin ni iranṣẹ mi tí mo yàn; kí ẹ lè mọ̀ mí, kí ẹ sì gbà mí gbọ́, kí ó sì ye yín pé, Èmi ni. A kò dá Ọlọrun kankan ṣáájú mi, òmíràn kò sì ní wáyé lẹ́yìn mi.
11 “Èmi ni OLUWA, kò sí olùgbàlà kan, yàtọ̀ sí mi.
12 Mo ti sọ̀rọ̀ ìṣípayá, mo ti gba eniyan là, mo sì ti kéde, nígbà tí kò sí Ọlọrun àjèjì láàrin yín; ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí mi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
13 Èmi ni Ọlọrun, láti ìsinsìnyìí lọ, Èmi ni. Kò sí ẹnìkan tí ó lè gba eniyan kalẹ̀ lọ́wọ́ mi: Ta ni le dínà ohun tí mo bá níí ṣe?”
14 OLUWA, Ẹni Mímọ́ Israẹli, Olùràpadà yín, ní, “N óo ranṣẹ sí Babiloni nítorí yín, n óo dá gbogbo ọ̀pá ìlẹ̀kùn ibodè, ariwo ẹ̀rín àwọn ará Kalidea yóo sì di ẹkún.
15 Èmi ni OLUWA, Ẹni Mímọ́ yín, Ẹlẹ́dàá Israẹli, Ọba yín.”
16 OLUWA tí ó la ọ̀nà sí ojú òkun, tí ó la ọ̀nà lórí agbami ńlá;
17 ẹni tí ó kó kẹ̀kẹ́ ogun ati ẹṣin jáde, ogun, ati àwọn ọmọ-ogun; wọ́n dùbúlẹ̀ wọn kò lè dìde mọ́, wọ́n kú bí iná fìtílà.
18 ÓLUWA ní, “Ẹ gbàgbé àwọn ohun àtijọ́, kí ẹ sì mú ọkàn kúrò ninu ohun tí ó ti kọjá.
19 Ẹ wò ó! Mò ń ṣe nǹkan titun ó ti yọ jáde nisinsinyii, àbí ẹ kò ṣe akiyesi rẹ̀? N óo la ọ̀nà ninu aginjù, n óo sì mú kí omi máa ṣàn ninu aṣálẹ̀.
20 Àwọn ẹranko ìgbẹ́ yóo máa yìn mí lógo, ati àwọn ọ̀fàfà ati ògòǹgò; nítorí pé mo ti ṣe odò ńlá fún wọn ninu aṣálẹ̀, kí àwọn àyànfẹ́ mi lè máa rí omi mu:
21 Àwọn tí mo fọwọ́ mi dá fún ara mi, kí wọ́n lè kéde ògo mi.
22 “Sibẹsibẹ, ẹ kò ké pè mí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, ọ̀rọ̀ mi ti su yín, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
23 Ẹ kò wá fi aguntan rúbọ sí mi, tabi kí ẹ wá fi ẹbọ rírú bu ọlá fún mi. N kò fi tipátipá mu yín rúbọ, bẹ́ẹ̀ ni n kò sọ pé dandan ni kí ẹ mú turari wá.
24 Ẹ kò fowó yín ra turari olóòórùn dídùn fún mi, tabi kí ẹ fi ọ̀rá ẹbọ yín tẹ́ mi lọ́rùn. Kàkà bẹ́ẹ̀ ẹ̀ ń fi ẹ̀ṣẹ̀ yín yọ mí lẹ́nu, ẹ sì ń dààmú mi pẹlu àìdára yín.
25 Èmi, èmi ni mo pa ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́, nítorí ti ara mi; n kò sì ní ranti àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín mọ́.
26 “Ẹ rán mi létí ọ̀rọ̀ yín kí á jọ ṣàríyànjiyàn; ẹ ro ẹjọ́ tiyín, kí á lè da yín láre.
27 Baba ńlá yín àkọ́kọ́ ṣẹ̀, àwọn aṣiwaju yín náà sì ṣẹ̀ mí.
28 Nítorí náà mo sọ àwọn olórí ibi mímọ́ mi di aláìmọ́, mo fi Jakọbu sílẹ̀ fún ìparun; mo sì sọ Israẹli di ẹni ẹ̀sín.”
1 OLUWA ní: “Ṣugbọn nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu iranṣẹ mi ẹ̀yin ọmọ Israẹli, àyànfẹ́ mi.
2 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA, Ẹlẹ́dàá yín wí, ẹni tí ó ṣẹ̀dá yín láti inú oyún, tí yóo sì ràn yín lọ́wọ́: Ẹ má bẹ̀rù ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, iranṣẹ mi, Jeṣuruni, ẹni tí mo yàn.
3 “N óo tú omi sórí ilẹ̀ tí òùngbẹ ń gbẹ n óo sì ṣe odò sórí ilẹ̀ gbígbẹ. N óo tú ẹ̀mí mi sórí àwọn ọmọ yín, n óo da ibukun mi sórí arọmọdọmọ yín,
4 wọn óo rúwé bíi koríko inú omi àní, bíi igi wilo lẹ́bàá odò tí ń ṣàn.
5 “Ẹnìkan yóo wí pé, ‘OLUWA ló ni mí.’ Ẹnìkejì yóo pe ara rẹ̀ ní orúkọ Jakọbu. Ẹlòmíràn yóo kọ ‘Ti OLUWA ni’ sí apá rẹ̀ yóo máa fi orúkọ Israẹli ṣe àpèjá orúkọ rẹ̀.”
6 Gbọ́ ohun tí OLUWA, ọba Israẹli ati Olùràpadà rẹ̀ wí, OLUWA àwọn ọmọ ogun, ó ní, “Èmi ni ẹni ìbẹ̀rẹ̀ ati ẹni òpin; lẹ́yìn mi, kò sí Ọlọrun mìíràn.
7 Ta ni ó dàbí mi? Kí olúwarẹ̀ sọ̀rọ̀ kí ó kéde rẹ̀ níwájú mi. Ẹni tí ó bá ti kéde láti ìbẹ̀rẹ̀, nípa àwọn nǹkan tí yóo ṣẹlẹ̀, kí wọn sọ ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ fún wa.
8 Má bẹ̀rù, má sì fòyà. Ṣebí mo ti sọ fún ọ tipẹ́, mo ti kéde rẹ̀, ìwọ sì ni ẹlẹ́rìí mi: Ǹjẹ́ Ọlọrun mìíràn wà lẹ́yìn mi? Kò tún sí àpáta kan mọ́, n kò mọ ọ̀kan kan.”
9 Asán ni àwọn tí ń gbẹ́ ère, ohun tí inú wọn dùn sí kò lérè. Àwọn tí ń jẹ́rìí wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ nǹkan, ojú ìbá le tì wọ́n.
10 Ta ló ṣe oriṣa, ta ló sì yá ère tí kò lérè?
11 Ojú yóo ti gbogbo wọn; eniyan sá ni wọ́n. Ẹ jẹ́ kí gbogbo wọn pésẹ̀, kí wọ́n jáde wá. Ìpayà yóo bá wọn, ojú yóo sì ti gbogbo wọn papọ̀.
12 Alágbẹ̀dẹ a mú irin, a fi sinu iná, a máa fi ọmọ owú lù ú, a sì fi agbára rẹ̀ rọ ọ́ bí ó ti fẹ́ kí ó rí. Ebi a pa á, àárẹ̀ a sì mú un; kò ní mu omi, a sì máa rẹ̀ ẹ́.
13 Agbẹ́gilére a ta okùn sára igi, a fi ẹfun fa ìlà sí i, a fi ìwọ̀n wọ̀n ọ́n, a sì gbẹ́ ẹ bí eniyan: ẹwà rẹ̀ a dàbí ti eniyan, wọn a sì kọ́lé fún un.
14 Ó lè gé igi kedari lulẹ̀, tabi kí ó gbin igi Sipirẹsi, tabi igi Oaku, kí ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrin àwọn igi inú igbó. Ó sì lè gbin igi kedari kan, omi òjò a sì mú kí ó dàgbà.
15 Lẹ́yìn náà igi yìí di igi ìdáná: Eniyan óo gé ninu rẹ̀, yóo fi dáná yá; yóo gé ninu rẹ̀ yóo fi dáná oúnjẹ; yóo gé ninu rẹ̀, yóo fi gbẹ́ ère, yóo máa bọ ọ́. Eniyan á wá sọ igi lásán tí ó gbẹ́ di oriṣa, á sì máa foríbalẹ̀ fún un.
16 Yóo fi ìdajì rẹ̀ dáná, yóo fi se oúnjẹ, yóo fi se ẹran rẹ̀ pẹlu. Yóo jẹun, yóo jẹran, yóo yó; yóo tún yáná. Yóo ní, “Áà! Ooru mú mi nítorí mo rí iná yá.”
17 Yóo fi èyí tí ó kù gbẹ́ ère oriṣa rẹ̀, yóo máa foríbalẹ̀ fún un, yóo máa bọ ọ́, yóo máa gbadura sí i pé, “Gbà mí, nítorí ìwọ ni Ọlọrun mi.”
18 Wọn kò mọ nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni òye kò yé wọn. Nǹkankan ti bò wọ́n lójú kí wọn má baà lè ríran; ó sì ti sé wọn lọ́kàn kí òye má baà yé wọn.
19 Kò sí ẹni tí ó ronú wò, tabi tí ó ní ìmọ̀ tabi òye, láti wí pé: “Ìdajì igi yìí ni mo fi dáná tí mo fi se oúnjẹ, tí mo sì fi se ẹran tí mo jẹ. Kí ló wá dé tí n óo ṣe fi ìyókù gbẹ́ ère kí n máa bọ ọ́? Ṣé ìtì igi lásán ló yẹ kí n máa foríbalẹ̀ fún, kí n máa bọ?”
20 Kò yàtọ̀ sí ẹni tí ń pe eérú ní oúnjẹ. Èrò ẹ̀tàn ti ṣì í lọ́nà, kò sì lè gba ara rẹ̀ kalẹ̀ tabi kí ó bi ara rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ irọ́ kọ́ ni ohun tí ó wà lọ́wọ́ mi yìí?”
21 Jakọbu, ranti àwọn nǹkan wọnyi, nítorí pé iranṣẹ mi ni ọ́, ìwọ Israẹli. Èmi ni mo ṣẹ̀dá rẹ, iranṣẹ mi ni ọ́, n kò jẹ́ gbàgbé rẹ, Israẹli.
22 Mo ti ká àìdára rẹ kúrò bí awọsanma, mo ti gbá ẹ̀ṣẹ̀ rẹ dànù bí ìkùukùu. Pada sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ pada.
23 Ẹ hó ìhó ayọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí OLUWA ti ṣe é. Ẹ pariwo, ẹ̀yin ìsàlẹ̀ ilẹ̀. Ẹ kọrin, ẹ̀yin òkè ńlá, ìwọ igbó ati igi inú rẹ̀, nítorí OLUWA ti ra Jakọbu pada, yóo sì ṣe ara rẹ̀ lógo ní Israẹli.
24 Gbọ́ ohun tí OLUWA, Olùràpadà rẹ wí, ẹni tí ó ṣẹ̀dá rẹ láti inú oyún. Ó ní, “Èmi ni OLUWA, tí mo dá ohun gbogbo. Èmi nìkan ni mo tẹ́ ojú ọ̀run, tí mo sì dá ilẹ̀ ayé tẹ́,
25 èmi tí mo sọ àmì àwọn tí ń woṣẹ́ èké di asán, tí mo sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀. Mo yí ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n po mo sì sọ ọgbọ́n wọn di òmùgọ̀.
26 Èmi tí mo jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ iranṣẹ mi, tí mo sì mú ìmọ̀ àwọn ikọ̀ mi ṣẹ, èmi tí mo wí fún Jerusalẹmu pé, ‘Àwọn eniyan yóo máa gbé inú rẹ,’ tí mo sì wí fún àwọn ìlú Juda pé, ‘A óo tún odi yín mọ, n óo sì tún yín kọ́.’
27 Èmi tí mo pàṣẹ fún agbami òkun pé, ‘Gbẹ! n óo mú kí àwọn odò rẹ gbẹ;’
28 èmi tí mo sọ fún Kirusi pé: ‘Ìwọ ni ọba tí n óo yàn tí yóo mú gbogbo ìpinnu mi ṣẹ;’ tí mo sọ fún Jerusalẹmu pé: ‘A óo tún odi rẹ̀ mọ,’ tí mo sì sọ fún Tẹmpili pé, ‘A óo tún fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀.’ ”
1 Ohun tí OLUWA sọ fún kirusi, ẹni tí ó fi àmì òróró yàn nìyí: Ẹni tí OLUWA di ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú, tí ó lò, láti rẹ àwọn orílẹ̀-èdè sílẹ̀ níwájú rẹ̀, láti tú àmùrè àwọn ọba, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀, kí ẹnubodè má lè tì.
2 OLUWA ní, “N óo lọ ṣáájú rẹ, n óo sọ àwọn òkè ńlá di pẹ̀tẹ́lẹ̀; n óo fọ́ ìlẹ̀kùn idẹ, n óo sì gé ọ̀pá ìlẹ̀kùn irin.
3 N óo fún ọ ní ìṣúra tí wọ́n fi pamọ́ sinu òkùnkùn, ati àwọn nǹkan tí wọ́n kó pamọ́ síkọ̀kọ̀; kí o lè mọ̀ pé èmi, OLUWA, Ọlọrun Israẹli, ni mo pè ọ́ ní orúkọ rẹ.
4 Nítorí Jakọbu, iranṣẹ mi, ati Israẹli, àyànfẹ́ mi, mo pè ọ́ ní orúkọ rẹ. Mo pe orúkọ rẹ ní àpèjá, bẹ́ẹ̀ ni o kò mọ̀ mí.
5 “Èmi ni OLUWA kò sí ẹlòmíràn, kò sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn mi. Mo dì ọ́ ní àmùrè bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o kò mọ̀ mí.
6 Kí àwọn eniyan lè mọ̀ pé, láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi. Èmi ni OLUWA, kò tún sí ẹlòmíràn.
7 Èmi ni mo dá ìmọ́lẹ̀ ati òkùnkùn, èmi ni mo dá alaafia ati àjálù: Èmi ni OLUWA tí mo ṣe gbogbo nǹkan wọnyi.
8 Rọ òjò sílẹ̀, ìwọ ọ̀run, kí ojú ọ̀run rọ̀jò òdodo sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ lanu, kí ìgbàlà lè yọ jáde. Jẹ́ kí ó mú kí òdodo yọ jáde pẹlu, èmi OLUWA ni mo ṣẹ̀dá rẹ̀ bẹ́ẹ̀.
9 “Ẹni tí ń bá ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà gbé! Ìkòkò tí ń bá amọ̀kòkò jà. Ṣé amọ̀ lè bèèrè lọ́wọ́ ẹni tí ń mọ ọ́n pé: ‘Kí ni ò ń mọ?’ Tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Nǹkan tí ò ń mọ kò ní ìgbámú?’
10 Ẹnìkan lè bi baba rẹ̀ pé: ‘Irú kí ni o bí?’ Tabi kí ó bi ìyá rẹ̀ léèrè pé: ‘Irú ọmọ wo ni o bí yìí?’ Olúwarẹ̀ gbé!”
11 OLUWA, Ẹni Mímọ́ Israẹli, ẹlẹ́dàá rẹ ni, “Ṣé ẹ óo máa bi mí ní ìbéèrè nípa àwọn ọmọ mi ni, tabi ẹ óo máa pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi?
12 Èmi ni mo dá ayé, tí mo dá eniyan sórí rẹ̀. Ọwọ́ mi ni mo fi ta ojú ọ̀run bí aṣọ, tí mo sì pàṣẹ fún oòrùn, òṣùpá ati àwọn ìràwọ̀.
13 Èmi ni mo gbé Kirusi dìde ninu òdodo mi, n óo mú kí ó ṣe nǹkan bí ó ti tọ́; òun ni yóo tún ìlú mi kọ́, yóo sì dá àwọn eniyan mi tí wọ́n wà ní ìgbèkùn sílẹ̀, láìgba owó ati láìwá èrè kan.” OLUWA àwọn ọmọ ogun ló sọ bẹ́ẹ̀.
14 Ó ní, “Àwọn ọrọ̀ ilẹ̀ Ijipti ati àwọn ẹrù ilẹ̀ Etiopia, ati àwọn ọkunrin Seba tí wọn ṣígbọnlẹ̀, wọn óo tọ̀ ọ́ wá, wọn óo di tìrẹ, wọn óo sì máa tẹ̀lé ọ. Wọn óo wá, pẹlu ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ lẹ́sẹ̀ wọn, wọn óo sì wólẹ̀ fún ọ. Wọn óo máa bẹ̀ ọ́ pé, ‘Lọ́dọ̀ rẹ nìkan ni Ọlọrun wà, kò tún sí Ọlọrun mìíràn. Kò sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn rẹ.’ ”
15 Nítòótọ́, ìwọ ni Ọlọrun tí ó ń fi ara pamọ́, Ọlọrun Israẹli, Olùgbàlà.
16 Gbogbo àwọn oriṣa ni a óo dójú tì, ìdààmú yóo sì bá wọn. Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère yóo bọ́ sinu ìdààmú papọ̀.
17 Ṣugbọn OLUWA gba Israẹli là, títí ayé sì ni ìgbàlà rẹ̀. Ojú kò ní tì ọ́, bẹ́ẹ̀ ni o kò ní dààmú, títí lae.
18 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí, OLUWA tí ó dá ọ̀run. (Òun ni Ọlọrun.) Òun ni ó dá ilẹ̀, tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, kò dá a ninu rúdurùdu, ṣugbọn ó dá a kí eniyan lè máa gbé inú rẹ̀ Ó ní, “Èmi ni OLUWA, kò sí Ọlọrun mìíràn.
19 N kò sọ ọ́ níkọ̀kọ̀, ninu òkùnkùn. N kò sọ fún arọmọdọmọ Jakọbu pé: ‘Ẹ máa wá mi ninu rúdurùdu.’ Òtítọ́ ni Èmi OLUWA sọ. Ohun tí ó tọ́ ni mò ń kéde.”
20 OLUWA ní: “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ wá, ẹ jọ súnmọ́ bí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kù ninu àwọn orílẹ̀-èdè. Aláìlóye ni àwọn tí ń gbẹ́ ère igi lásán kiri, tí wọ́n sì ń gbadura sí oriṣa tí kò lè gbànìyàn là.
21 Ẹ sọ̀rọ̀ jáde, kí ẹ sì ro ẹjọ́ tiyín, jẹ́ kí wọ́n jọ gbìmọ̀ pọ̀. Ta ló sọ èyí láti ìgbà laelae? Ta ló kéde rẹ̀ láti ìgbà àtijọ́? Ṣebí èmi OLUWA ni? Kò tún sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn mi. Ọlọrun Olódodo ati Olùgbàlà kò tún sí ẹnìkan mọ́, àfi èmi.
22 “Ẹ yipada sí mi kí á gbà yín là, gbogbo ẹ̀yin òpin ayé. Nítorí èmi ni Ọlọrun, kò tún sí ẹlòmíràn mọ́.
23 Mo ti fi ara mi búra, mo sì fi ẹnu mi sọ̀rọ̀ pẹlu òtítọ́ inú, ọ̀rọ̀ tí kò ní yipada: ‘Gbogbo orúnkún ni yóo wólẹ̀ fún mi, èmi ni gbogbo eniyan yóo sì búra pé àwọn óo máa sìn.’
24 “Nípa èmi nìkan ni àwọn eniyan yóo máa pé, ‘Ninu OLUWA ni òdodo ati agbára wà.’ Gbogbo àwọn tí ń bá a bínú yóo pada wá sọ́dọ̀ rẹ̀ pẹlu ìtìjú.
25 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli yóo ṣẹgun, wọn yóo sì ṣògo ninu OLUWA.
1 “Oriṣa Bẹli tẹríba, oriṣa Nebo doríkodò. Orí àwọn ẹran ọ̀sìn ati mààlúù ni àwọn oriṣa wọn wà. Àwọn nǹkan tí ẹ̀ ń rù kiri wá di ẹrù, tí àwọn ẹranko tí ó ti rẹ̀ ń rù.
2 Àwọn mejeeji jọ tẹríba, wọ́n jọ doríkodò, wọn ò lè gba àwọn ẹrù wọn kalẹ̀. Àwọn pàápàá yóo lọ sí ìgbèkùn.
3 “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ará ilé Jakọbu, ati gbogbo ará ilé Israẹli tí ó ṣẹ́kù; ẹ̀yin tí mo pọ̀n láti ọjọ́ tí wọ́n ti bi yín, tí mo sì gbé láti inú oyún.
4 Èmi náà ni, títí di ọjọ́ ogbó yín, n óo gbé yín títí tí ẹ óo fi hewú lórí. Èmi ni mo da yín, n óo sì máa tọ́jú yín, n óo máa gbé yín, n óo sì gbà yín là.
5 “Ta ni ẹ óo fi mí wé? Ta ni ẹ óo fi díwọ̀n mi? Ta ni ẹ lè fi wé mi, kí á lè jọ jẹ́ bákan náà?
6 Àwọn kan ń kó ọpọlọpọ wúrà jáde ninu àpò, wọ́n sì ń wọn fadaka lórí ìwọ̀n. Wọ́n sanwó ọ̀yà fún alágbẹ̀dẹ wúrà, ó bá wọn fi dá oriṣa. Wọ́n wá ń foríbalẹ̀ fún un, wọ́n ń sìn ín.
7 Wọn á gbé e lé èjìká wọn, wọn á gbé e sípò rẹ̀, á sì dúró kabẹ̀. Kò ní le kúrò níbẹ̀ lọ sí ibìkankan. Bí eniyan bá ké pè é, kò lè gbọ́, kò lè yọ eniyan ninu ìṣòro rẹ̀.
8 “Ẹ ranti èyí, kí ẹ dà á rò, ẹ fi ọkàn rò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀.
9 Ẹ ranti àwọn nǹkan ti àtijọ́, nítorí pé èmi ni Ọlọrun, kò sí Ọlọrun mìíràn mọ́. Èmi ni Ọlọrun, kò sí ẹni tí ó dà bí mi.
10 Láti ìbẹ̀rẹ̀ ni èmi tíí sọ ohun tí ó gbẹ̀yìn. Láti ìgbà àtijọ́, ni mo tí ń sọ àwọn nǹkan tí kò ì tíì ṣẹlẹ̀. Èmi a máa sọ pé: ‘Àbá mi yóo ṣẹ, n óo sì mú ìpinnu mi ṣẹ.’
11 Mo pe idì láti ìlà oòrùn, mo sì ti pe ẹni tí yóo mú àbá mi ṣẹ láti ilẹ̀ òkèèrè wá. Mo ti sọ̀rọ̀, n óo sì mú un ṣẹ, mo ti ṣe ìpinnu, n óo sì ṣe é.
12 “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin aláìgbọràn, ẹ̀yin tí ẹ jìnnà sí ìgbàlà.
13 Mo mú ìdáǹdè mi wá sí tòsí, kò jìnnà mọ́, ìgbàlà mi kò ní pẹ́ dé. N óo fi ìgbàlà mi sí Sioni, fún Israẹli, ògo mi.”
1 Sọ̀kalẹ̀ kí o jókòó ninu eruku, ìwọ Babiloni. Jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀, láìsí ìtẹ́-ọba, ìwọ ọmọbinrin Kalidea. A kò ní pè ọ́ ní ẹlẹgẹ́ ati aláfẹ́ mọ́.
2 Gbé ọlọ kí o máa lọ ọkà, ṣí aṣọ ìbòjú rẹ kúrò, ká aṣọ rẹ sókè, kí o ṣí ẹsẹ̀ rẹ sílẹ̀, kí o sì la odò kọjá.
3 A óo tú ọ sí ìhòòhò, a óo sì rí ìtìjú rẹ. N óo gbẹ̀san, n kò sì ní dá ẹnìkan kan sí.
4 Olùràpadà wa, tí ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun, ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
5 OLUWA wí nípa Kalidea pé: “Jókòó kí o dákẹ́ jẹ́ẹ́, kí o sì wọ inú òkùnkùn lọ, ìwọ ọmọbinrin Kalidea. Nítorí a kò ní pè ọ́ ní ayaba àwọn orílẹ̀-èdè mọ́.
6 Inú bí mi sí àwọn eniyan mi, mo sì sọ nǹkan ìní mi di ohun ìríra. Mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́, o kò ṣàánú wọn. O di àjàgà wúwo rẹ mọ́ àwọn arúgbó lọ́rùn.
7 O sọ pé ìwọ ni o óo máa jẹ́ ayaba títí lae, nítorí náà o kò kó àwọn nǹkan wọnyi lékàn, o kò sì ranti ìgbẹ̀yìn wọn.
8 “Nítorí náà, gbọ́ nisinsinyii, ìwọ tí o fẹ́ràn afẹ́ ayé, tí o jókòó láìléwu, tí ò ń sọ lọ́kàn rẹ pé, ‘Èmi nìkan ni mo wà, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi. N kò ní di opó, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní ṣòfò ọmọ.’
9 Ọ̀fọ̀ mejeeji ni yóo ṣe ọ́ lójijì, lọ́jọ́ kan náà: o óo ṣòfò ọmọ, o óo sì di opó, ibi yìí yóo dé bá ọ lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́. Ò báà lóṣó, kí o lájẹ̀ẹ́, kí àfọ̀ṣẹ rẹ sì múná jù bẹ́ẹ̀ lọ.
10 “Ọkàn rẹ balẹ̀ ninu iṣẹ́ ibi rẹ, o ní ẹnìkan kò rí ọ. Ọgbọ́n ati ìmọ̀ rẹ mú ọ ṣìnà, ò ń sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Èmi nìkan ní mo wà. Kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’
11 Ṣugbọn ibi yóo dé bá ọ, tí o kò ní lè dáwọ́ rẹ̀ dúró; àjálù yóo dé bá ọ, tí o kò ní lè ṣe ètùtù rẹ̀; ìparun yóo dé bá ọ lójijì, tí o kò ní mọ nǹkankan nípa rẹ̀.
12 Múra sí àfọ̀ṣẹ rẹ, sì múra si oṣó ṣíṣẹ́ jọ, tí o ti dáwọ́ lé láti kékeré, bóyá o óo tilẹ̀ yege, tabi bóyá o sì lè dẹ́rùba eniyan.
13 Ọpọlọpọ ìmọ̀ràn tí wọn fún ọ ti sú ọ; jẹ́ kí wọn dìde nílẹ̀ kí wọ́n gbà ọ́ wàyí, àwọn tí ó ń wojú ọ̀run, ati àwọn awòràwọ̀; tí wọn ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí ọ, nígbà tí oṣù bá ti lé.
14 “Wò ó! Wọ́n dàbí àgékù koríko, iná ni yóo jó wọn ráúráú, wọn kò sì ní lè gba ara wọn kalẹ̀, ninu ọ̀wọ́ iná. Eléyìí kì í ṣe iná tí eniyan ń yá, kì í ṣe iná tí eniyan lè jókòó níwájú rẹ̀.
15 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ẹ jọ ń ṣiṣẹ́ pọ̀ rí sí ọ, àwọn tí ẹ ti jọ ń ṣòwò pọ̀ láti ìgbà èwe rẹ. Olukuluku wọn ti ṣìnà lọ, kò sí ẹni tí yóo gbà ọ́ sílẹ̀.”
1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin ará ilé Jakọbu, ẹ̀yin tí à ń fi orúkọ Israẹli pè, ọmọ bíbí inú Juda, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń forúkọ OLUWA búra, tí ẹ jẹ́wọ́ Ọlọrun Israẹli, ṣugbọn tí kì í ṣe pẹlu òdodo tabi òtítọ́.
2 Ẹ̀ ń pe ara yín ní ará ìlú mímọ́, ẹ fẹ̀yìn ti Ọlọrun Israẹli, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun.
3 OLUWA ní, “Láti ìgbà àtijọ́ ni mo ti kéde, àwọn nǹkan tí yóo ṣẹlẹ̀, èmi ni mo sọ wọ́n jáde, tí mo sì fi wọ́n hàn. Lójijì mo ṣe wọ́n, nǹkan tí mo sọ sì ṣẹ.
4 Nítorí mo mọ̀ pé alágídí ni yín, olóríkunkun sì ni yín pẹlu.
5 Mo ti sọ fun yín láti ọjọ́ pípẹ́: kí wọn tó ṣẹlẹ̀, mo ti kéde wọn fun yín, kí ẹ má baà sọ pé, ‘oriṣa wa ni ó ṣe wọ́n, àwọn ère wa ni ó pàṣẹ pé kí wọn ṣẹlẹ̀.’
6 “Ẹ ti fetí ara yín gbọ́, nítorí náà, ẹ wo gbogbo èyí, ṣé ẹ kò ní kéde rẹ̀? Láti àkókò yìí lọ, n óo mú kí ẹ máa gbọ́ nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó farapamọ́ tí ẹ kò mọ̀.
7 Kò tíì pẹ́ tí a dá wọn, ẹ kò gbọ́ nípa wọn rí, àfi òní. Kí ẹ má baà wí pé: Wò ó, a mọ̀ wọ́n.
8 Ẹ kò gbọ́ ọ rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀. Ọjọ́ ti pẹ́ tí a ti di yín létí, nítorí mo mọ̀ pé ẹ óo hùwà àgàbàgebè, ọlọ̀tẹ̀ ni orúkọ tí mo mọ̀ yín mọ̀, láti ìgbà tí ẹ ti jáde ninu oyún.
9 “Mo dáwọ́ ibinu mi dúró ná, nítorí orúkọ mi, nítorí ìyìn mi ni mo ṣe dá a dúró fun yín, kí n má baà pa yín run.
10 Mo ti fọ̀ ọ́ mọ́, ṣugbọn kì í ṣe bí a tií fọ fadaka, mo dán yín wò ninu iná ìpọ́njú.
11 Nítorí tèmi, àní nítorí tèmi ni mo ṣe ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí kí ni ìdí rẹ̀ tí orúkọ mi yóo ṣe díbàjẹ́, n kò ní gbé ògo mi fún ẹlòmíràn.
12 “Tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi ìwọ Jakọbu, ìwọ Israẹli, ẹni tí mo pè, Èmi ni ẹni ìbẹ̀rẹ̀, èmi sì ni ẹni òpin.
13 Ọwọ́ mi ni mo fi fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọwọ́ ọ̀tún mi ni mo fi ta awọsanma sójú ọ̀run. Nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn jọ yọ síta.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ, kí ẹ gbọ́, èwo ninu wọn ni ó kéde nǹkan wọnyi? OLUWA fẹ́ràn rẹ̀, yóo mú ìfẹ́ inú rẹ̀ ṣẹ lórí Babiloni, yóo sì gbógun ti àwọn ará Kalidea.
15 Èmi, àní èmi pàápàá ni mo sọ̀rọ̀, tí mo pè é, èmi ni mo mú un wá, yóo sì ṣe àṣeyege ninu àdáwọ́lé rẹ̀.
16 Ẹ súnmọ́ mi, kí ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, n kò sọ̀rọ̀ ní àṣírí, láti ìgbà tí ọ̀rọ̀ náà ti ṣe ni mo ti wà níbẹ̀.” Nisinsinyii, OLUWA, Ọlọrun, ati Ẹ̀mí rẹ̀ ti rán mi.
17 OLUWA, Olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, ní, “Èmi ni OLUWA Ọlọrun rẹ, tí ń kọ́ ọ ní ohun tí yóo ṣe ọ́ ní anfaani, tí ń darí rẹ, sí ọ̀nà tí ó yẹ kí o gbà.
18 “Ìbá jẹ́ pé o ti fetí sí òfin mi, alaafia rẹ ìbá máa ṣàn bí odò, òdodo rẹ ìbá lágbára bi ìgbì omi òkun.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá pọ̀ bí iyanrìn, arọmọdọmọ rẹ ìbá pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀ tí kò lóǹkà. Orúkọ wọn kì bá tí parẹ́ títí ayé, bẹ́ẹ̀ ni kì bá tí parun lae níwájú mi.”
20 Ẹ jáde kúrò ní Babiloni, ẹ sá kúrò ní Kalidea, ẹ sọ ọ́ pẹlu ayọ̀, ẹ kéde rẹ̀, ẹ máa ròyìn rẹ̀ lọ títí dè òpin ayé, pé “OLUWA ti ra Jakọbu iranṣẹ rẹ̀ pada.”
21 Òùngbẹ kò gbẹ wọ́n, nígbà tí ó mú wọn la inú aṣálẹ̀ kọjá, ó tú omi jáde fún wọn láti inú àpáta, ó la àpáta, omi sì tú jáde.
22 OLUWA sọ pé, “Kò sí alaafia fún àwọn eniyan burúkú.”
1 Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ilẹ̀ etí òkun. Ẹ fetí sílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ará ilẹ̀ òkèèrè, láti inú oyún ni OLUWA ti pè mí, láti inú ìyá mi wá ni ó ti dárúkọ mi.
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà mímú, ó fi mí pamọ́ sí ibi òjìji ọwọ́ rẹ̀, ó ṣe mí ní ọfà tí ó mú, ó fi mí pamọ́ sinu apó rẹ̀.
3 Ó sọ fún mi pé, “Iranṣẹ mi ni ọ́, ìwọ Israẹli, àwọn eniyan óo máa yìn mí lógo nítorí rẹ.”
4 Ṣugbọn mo dáhùn pé, “Mo ti ṣiṣẹ́ àṣedànù. Mo ti lo agbára mi ṣòfò, mo ti fi ṣe àṣedànù, sibẹsibẹ ẹ̀tọ́ mi ń bẹ lọ́dọ̀ OLUWA.” Ẹ̀san mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọrun mi, yóo san án fún mi.
5 Nisinsinyii, OLUWA, tí ó ṣẹ̀dá mi ninu oyún, kí n lè jẹ́ iranṣẹ rẹ̀, láti mú Jakọbu pada tọ̀ ọ́ wá, ati láti mú kí Israẹli kórajọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀; nítorí mo níyì lójú OLUWA, Ọlọrun mi sì ti di agbára mi.
6 OLUWA ní nǹkan kékeré ni kí n jẹ́ iranṣẹ òun, láti gbé àwọn ẹ̀yà Jakọbu dìde, ati láti kó àwọn ọmọ Israẹli tí ó kù jọ. Ó ní òun óo fi mí ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè kí ìgbàlà òun lè dé òpin ayé.
7 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA, Olùràpadà Israẹli, ati Ẹni Mímọ́ rẹ̀, sọ, fún ẹni tí ayé ń gàn, tí àwọn orílẹ̀-èdè kórìíra, iranṣẹ àwọn aláṣẹ, ó ní, “Àwọn ọba yóo rí ọ, wọn óo dìde, àwọn ìjòyè yóo rí ọ, wọn óo sì dọ̀bálẹ̀. Nítorí OLUWA, tí ó jẹ́ olódodo, Ẹni Mímọ́ Israẹli, tí ó ti yàn ọ́.”
8 OLUWA ní, “Ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà mo dá ọ lóhùn, lọ́jọ́ ìgbàlà, mo ràn ọ́ lọ́wọ́. Mo ti pa ọ́ mọ́, mo sì ti fi ọ́ dá majẹmu pẹlu àwọn aráyé, láti fìdí ilẹ̀ náà múlẹ̀, láti pín ilẹ̀ tí ó ti di ahoro.
9 Kí o máa sọ fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n pé, ‘Ẹ jáde,’ ati fún àwọn tí ó wà ninu òkùnkùn pé, ‘Ẹ farahàn.’ Wọn óo rí ohun jíjẹ ní gbogbo ọ̀nà, gbogbo orí òkè yóo sì jẹ́ ibùjẹ fún wọn.
10 Ebi kò ní pa wọ́n, òùngbẹ kò sì ní gbẹ wọ́n, atẹ́gùn gbígbóná kò ní fẹ́ lù wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni oòrùn kò ní pa wọ́n, nítorí ẹni tí ó ṣàánú wọn ni yóo máa darí wọn, yóo sì mú wọn gba ẹ̀gbẹ́ omi tí ń ṣàn.
11 “N óo sọ gbogbo òkè mi di ojú ọ̀nà, n óo kún gbogbo òpópó ọ̀nà mi.
12 Wò ó! Òkèèrè ni èyí yóo ti wá, láti àríwá ati láti ìwọ̀ oòrùn, àní láti ilẹ̀ Sinimu.”
13 Kí ọ̀run kọrin ayọ̀, kí ayé kún fún ayọ̀, ẹ̀yin òkè, ẹ máa kọrin, nítorí, OLUWA ti tu àwọn eniyan rẹ̀ ninu, yóo ṣàánú àwọn eniyan rẹ̀ tí ìyà ń jẹ.
14 Sioni ń wí pé, “OLUWA ti kọ̀ mí sílẹ̀, Oluwa mi ti gbàgbé mi.”
15 OLUWA dáhùn pé, “Ǹjẹ́ abiyamọ le gbàgbé ọmọ tí ń fún lọ́mú? Ṣé ó le má ṣàánú ọmọ bíbí inú rẹ̀? Bí àwọn wọnyi tilẹ̀ gbàgbé. Èmi kò ní gbàgbé rẹ.
16 Wò ó! Mo ti fi gègé fín orúkọ rẹ sí àtẹ́lẹwọ́ mi, àwọn odi rẹ sì ńbẹ níwájú mi nígbà gbogbo.
17 “Àwọn ọmọ rẹ tí ń pada bọ̀ kíákíá, àwọn olùparun rẹ yóo jáde kúrò ninu rẹ.
18 Gbójú sókè, kí o wò yíká, gbogbo àwọn ọmọ rẹ péjọ, wọ́n tọ̀ ọ́ wá. OLUWA fi ara rẹ̀ búra pé, o óo gbé wọn wọ̀ bí nǹkan ọ̀ṣọ́ ara. O óo wọ̀ wọ́n bí ìgbà tí iyawo kó ohun ọ̀ṣọ́ wọ̀.
19 “Dájúdájú ilẹ̀ rẹ tí ó ti di aṣálẹ̀, ati àwọn tí ó ti di ahoro, yóo kéré fún àwọn tí yóo máa gbé inú rẹ̀ tí ó bá yá, a óo sì lé àwọn tí ó pa ọ́ run jìnnà sí ọ.
20 Àwọn ọmọ tí o bí ní àkókò ìgbèkùn rẹ yóo sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ pé, ‘Ibí yìí kéré jù fún wa, fún wa ní àyè sí i láti máa gbé.’
21 O óo bèèrè lọ́kàn ara rẹ nígbà náà pé, ‘Ta ni ó bí àwọn ọmọ wọnyi fún mi? Ṣebí àwọn ọmọ mi ti kú, mo ti yàgàn, mo sì lọ sí ìgbèkùn lóko ẹrú. Ta ni ó wá tọ́ àwọn wọnyi dàgbà? Ṣebí èmi nìkan ni mo ṣẹ́kù, níbo ni àwọn wọnyi ti wá?’ ”
22 OLUWA Ọlọrun ní, “Wò ó, n óo gbé ọwọ́ mi sókè sí àwọn orílẹ̀-èdè. N óo gbé àsíá mi sókè sí àwọn eniyan, wọn óo gbé àwọn ọmọ rẹ ọkunrin mọ́ àyà wọn wọn óo sì gbé àwọn ọmọ rẹ obinrin sí èjìká.
23 Àwọn ọba ni yóo máa tọ́jú rẹ bíi baba, àwọn ayaba yóo sì máa tọ́jú rẹ bí ìyá, ní ìdojúbolẹ̀ ni wọn óo máa tẹríba fún ọ, wọn óo sì máa pọ́n eruku ẹsẹ̀ rẹ lá. O óo wá mọ̀ nígbà náà pé èmi ni OLUWA, ojú kò ní ti àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé mi.”
24 Ǹjẹ́ a lè gba ìkógun lọ́wọ́ alágbára, tabi kí á gba òǹdè lọ́wọ́ òkúrorò eniyan?
25 OLUWA ní: “Bí ó bá tilẹ̀ ṣeéṣe láti gba òǹdè lọ́wọ́ alágbára, tabi láti gba ìkógun lọ́wọ́ òkúrorò eniyan. N óo bá àwọn tí ó ń bá ọ jà jà, n óo sì gba àwọn ọmọ rẹ là.
26 N óo mú kí àwọn tó ń ni ọ́ lára máa pa ara wọn jẹ: wọn óo máa mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn, bí ẹni mu ọtí, gbogbo ayé yóo sì mọ̀ nígbà náà pé, èmi ni OLUWA, Olùgbàlà rẹ, Olùràpadà rẹ, Ọlọrun alágbára Jakọbu.”
1 OLUWA ní: OLUWA ní: “Ìwé ìkọ̀sílẹ̀ tí mo fi kọ àwọn eniyan mi sílẹ̀ dà? Ta ni mo tà yín fún, tí mo jẹ lówó? Ẹ wò ó! Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín ni a ṣe tà yín, nítorí àìdára yín ni mo ṣe kọ̀ yín sílẹ̀.
2 “Kí ló dé tí mo wá àwọn eniyan mi tí n kò rí ẹnìkan; mo pè, ẹnikẹ́ni kò dá mi lóhùn? Ṣé n kò lágbára tó láti rà wọ́n pada ni; àbí n kò lágbára láti gba ni là? Wò ó! Ìbáwí lásán ni mo fi gbẹ́ omi òkun, tí mo sì fi sọ odò tí ń ṣàn di aṣálẹ̀, omi wọn gbẹ, òùngbẹ gbẹ àwọn ẹja inú wọn pa, wọ́n kú, wọ́n sì ń rùn.
3 Mo da òkùnkùn bo ojú ọ̀run bí aṣọ, mo ṣe aṣọ ọ̀fọ̀ ní ìbora fún wọn.”
4 OLUWA Ọlọrun ti fi ọ̀rọ̀ ìmọ̀ sí mi lẹ́nu. Kí n lè mọ bí a tií gba àwọn tí ọkàn wọn rẹ̀wẹ̀sì níyànjú. Ojoojumọ ni ó ń ṣí mi létí láràárọ̀, kí n lè máa gbọ́rọ̀ bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́.
5 OLUWA Ọlọrun ti ṣí mi létí, n kò sì ṣe oríkunkun, tabi kí n pada sẹ́yìn.
6 Mo tẹ́ ẹ̀yìn sílẹ̀ fún àwọn tí ń nani lẹ́gba; mo sì kọ ẹ̀rẹ̀kẹ́ sí àwọn tí ń fa eniyan ní irùngbọ̀n tu. N kò fojú pamọ́ nítorí ẹ̀gàn, bẹ́ẹ̀ ni n kò gbójú sá fún itọ́ títu síni lójú.
7 OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́, nítorí náà ojú kò tì mí; nítorí náà mo múra gírí, mo jẹ́ kí ojú mi le koko, mo sì mọ̀ pé ojú kò ní tì mí.
8 Ẹni tí yóo dá mi láre wà nítòsí, ta ló fẹ́ bá mi jà? Ta ló fẹ́ fi ẹ̀sùn kàn mí? Kí olúwarẹ̀ súnmọ́ tòsí mi, kí á jọ kojú ara wa?
9 Wò ó! OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́, ta ni yóo dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn ni yóo gbọ̀n dànù bí aṣọ, kòkòrò yóo sì jẹ wọ́n.
10 Ta ló bẹ̀rù OLUWA ninu yín, tí ń gbọ́ràn sí iranṣẹ rẹ̀ lẹ́nu, tí ń rìn ninu òkùnkùn, tí kò ní ìmọ́lẹ̀, ṣugbọn sibẹ, tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, tí ó fẹ̀yìn ti Ọlọrun rẹ̀.
11 Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń dáná, tí ẹ tan iná yí ara yín ká, ẹ máa rìn lọ ninu iná tí ẹ dá; ẹ máa la iná tí ẹ fi yí ara yín ká kọjá. Bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe fun yín. Ẹ óo wà ninu ìrora.
1 “Ẹ gbọ́ ẹ̀yin tí ẹ̀ ń sáré ìdáǹdè, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wá OLUWA, ẹ wo àpáta tí a mú lára rẹ̀, tí a fi gbẹ yín, ati kòtò ibi tí a ti wà yín jáde.
2 Ẹ wo Abrahamu baba yín, ati Sara tí ó bi yín. Òun nìkan ni nígbà tí mo pè é, tí mo súre fún un, tí mo sì sọ ọ́ di ọpọlọpọ eniyan.
3 “OLUWA yóo tu Sioni ninu, yóo tu gbogbo àwọn tí ó ṣòfò ninu rẹ̀ ninu; yóo sì sọ aṣálẹ̀ rẹ̀ dàbí Edẹni, ọgbà OLUWA. Ayọ̀ ati ìdùnnú ni yóo máa wà ninu rẹ̀, pẹlu orin ọpẹ́ ati orin ayọ̀.
4 “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin eniyan mi, ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, òfin kan yóo ti ọ̀dọ̀ mi jáde, ìdájọ́ òdodo mi yóo jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún àwọn eniyan.
5 Ìdáǹdè mi súnmọ́ tòsí, ìgbàlà mi sì ti ń yọ bọ̀. Èmi ni n óo máa ṣe àkóso àwọn eniyan, àwọn erékùṣù yóo gbẹ́kẹ̀lé mi, ìrànlọ́wọ́ mi ni wọn yóo sì máa retí.
6 Ẹ gbójú sókè, ẹ wo ojú ọ̀run, kí ẹ sì wo ayé ní ìsàlẹ̀. Ọ̀run yóo parẹ́ bí èéfín, ayé yóo gbó bí aṣọ, àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ yóo sì kú bíi kòkòrò; ṣugbọn títí lae ni ìgbàlà mi, ìdáǹdè mi kò sì ní lópin.
7 “Ẹ̀yin tí ẹ mọ òdodo, ẹ gbọ́ ohùn mi, ẹ̀yin tí ẹ fi tọkàntọkàn gba òfin mi, ẹ má bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn eniyan; ẹ má sì jẹ́ kí yẹ̀yẹ́ wọn já a yín láyà.
8 Ikán yóo jẹ wọ́n bí aṣọ, kòkòrò yóo jẹ wọ́n bí òwú; ṣugbọn ìdáǹdè mi yóo wà títí lae, ìgbàlà mi yóo sì wà láti ìran dé ìran.”
9 Jí, jí! Dìde, OLUWA, jí pẹlu agbára; jí bí ìgbà àtijọ́, bí o ti ṣe sí ìran wa látijọ́. Ṣebí ìwọ ni o gé Rahabu wẹ́lẹwẹ̀lẹ, tí o fi idà gún diragoni?
10 Àbí ìwọ kọ́ ni o mú kí omi òkun gbẹ, omi inú ọ̀gbun ńlá; tí o sọ ilẹ̀ òkun di ọ̀nà, kí àwọn tí o rà pada lè kọjá?
11 Àwọn tí OLUWA rà pada yóo pada wá, pẹlu orin ni wọn óo pada wá sí Sioni. Adé ayọ̀ ni wọn óo dé sórí, wọn óo láyọ̀, inú wọn yóo dùn; ìbànújẹ́ ati ẹ̀dùn wọn yóo sì fò lọ.
12 “Èmi fúnra mi ni mò ń tù ọ́ ninu, ta ni ọ́, tí o fi ń bẹ̀rù eniyan tí yóo kú? Ìwọ ń bẹ̀rù ọmọ eniyan tí a dá, bíi koríko.
13 O gbàgbé OLUWA ẹlẹ́dàá rẹ, tí ó ta ojú ọ̀run bí aṣọ, tí ó fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀. O wá ń fi gbogbo ọjọ́ ayé bẹ̀rù ibinu àwọn aninilára, nítorí wọ́n múra tán láti pa ọ́ run? Ibinu àwọn aninilára kò ní dé ọ̀dọ̀ rẹ mọ́.
14 Láìpẹ́, a óo tú àwọn tí a tẹ̀ lórí ba sílẹ̀. Wọn kò ní kú, wọn kò ní wọ inú isà òkú, wọn kò sì ní wá oúnjẹ tì.
15 “Nítorí èmi ni OLUWA, Ọlọrun rẹ, ẹni tí ó rú òkun sókè, tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo; OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ mi.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ọ lẹ́nu, mo ti pa ọ́ mọ́ lábẹ́ òjìji ọwọ́ mi. Èmi ni mo fi ojú ọ̀run sí ipò rẹ̀, tí mo fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí mo sì sọ fún ìlú Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni eniyan mi.’ ”
17 Jí, jí! Dìde, ìwọ Jerusalẹmu. Ìwọ tí o ti rí ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ibinu OLUWA, ìwọ tí OLUWA ti fi ibinu jẹ níyà, tí ojú rẹ wá ń pòòyì.
18 Kò sí ẹni tí yóo tọ́ ọ sọ́nà, ninu gbogbo àwọn ọmọ tí o ti bí, kò sí ẹni tí yóo fà ọ́ lọ́wọ́, ninu gbogbo ọmọ tí o tọ́ dàgbà.
19 Àjálù meji ló dé bá ọ, ta ni yóo tù ọ́ ninu: Ìsọdahoro ati ìparun, ìyàn ati ogun, ta ni yóo tù ọ́ ninu?
20 Àárẹ̀ mú àwọn ọmọ rẹ, wọ́n sùn káàkiri ní gbogbo òpópó, bí ìgalà tí ó bọ́ sinu àwọ̀n. Ibinu OLUWA rọ̀jò lé wọn lórí, àní ìbáwí Ọlọrun rẹ.
21 Nítorí náà, ẹ̀yin tí à ń fi ìyà jẹ, ẹ gbọ́ èyí; ẹ̀yin tí ẹ ti yó láì tíì mu ọtí,
22 Oluwa rẹ, àní OLUWA Ọlọrun rẹ, tí ń bẹ̀bẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ ní, “Wò ó! Mo ti gba ife àmutagbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n lọ́wọ́ rẹ, O kò ní rí ibinu mi mọ́.
23 Àwọn tí ń dá ọ lóró ni yóo rí ibinu mi, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí á gba orí rẹ kọjá;’ tí wọ́n sọ ẹ̀yìn rẹ di ilẹ̀ẹ́lẹ̀, tí wọ́n sọ ọ́ di ojú ọ̀nà wọn, tí wọn óo máa gbà kọjá.”
1 Jí, Sioni, jí! Gbé agbára rẹ wọ̀ bí aṣọ, gbé ẹwà rẹ wọ̀ bí ẹ̀wù, ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́; nítorí àwọn aláìkọlà ati aláìmọ́, kò ní wọ inú rẹ mọ́.
2 Dìde, gbọnranù kúrò ninu erùpẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu tí ó wà ninu ìdè. Tú okùn tí a dè mọ́ ọ lọ́rùn kúrò, ìwọ Sioni tí ó wà ninu ìdè.
3 Nítorí OLUWA ní, “Ọ̀fẹ́ ni a mu yín lẹ́rú, ọ̀fẹ́ náà sì ni a óo rà yín pada.
4 Lákọ̀ọ́kọ́, àwọn eniyan mi lọ ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Ijipti, lẹ́yìn náà, àwọn ará Asiria pọ́n wọn lójú láì nídìí.
5 Ṣugbọn nisinsinyii, kí ni mo rí yìí? Wọ́n mú àwọn eniyan mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́, àwọn alákòóso wọn ń pẹ̀gàn, orúkọ mi wá di nǹkan yẹ̀yẹ́?
6 Nítorí náà àwọn eniyan mi yóo mọ orúkọ mi, wọn óo sì mọ̀ ní ọjọ́ náà pé, èmi tí mò ń sọ̀rọ̀, èmi náà nìyí.”
7 Ẹsẹ̀ ẹni tí ń mú ìyìn rere bọ̀ ti dára tó lórí òkè, ẹni tí ń kéde alaafia, tí ń mú ìyìn rere bọ̀, tí sì ń kéde ìgbàlà, tí ń wí fún Sioni pé, “Ọlọrun rẹ jọba.”
8 Gbọ́, àwọn aṣọ́de rẹ gbóhùn sókè, gbogbo wọn jọ ń kọrin ayọ̀, nítorí wọ́n jọ fi ojú ara wọn rí i, tí OLUWA pada dé sí Sioni.
9 Ẹ jọ máa kọrin pọ̀, gbogbo ilẹ̀ Jerusalẹmu tí a sọ di aṣálẹ̀, nítorí OLUWA yóo tu àwọn eniyan rẹ̀ ninu, yóo ra Jerusalẹmu pada.
10 OLUWA yóo lo agbára mímọ́ rẹ̀, lójú àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo eniyan, títí dé òpin ayé, yóo sì rí ìgbàlà Ọlọrun wa.
11 Ẹ jáde, ẹ jáde ẹ kúrò níbẹ̀, ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan, ẹ jáde kúrò láàrin rẹ̀, kí ẹ sì wẹ ara yín mọ́, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò OLUWA.
12 Nítorí pé ẹ kò ní fi ìkánjú jáde, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní sáré jáde. Nítorí OLUWA yóo máa lọ níwájú yín, Ọlọrun Israẹli yóo sì wà lẹ́yìn yín.
13 Wò ó! Iranṣẹ mi yóo ṣe àṣeyọrí a óo gbé e ga, a óo gbé e lékè; yóo sì di ẹni gíga,
14 Ẹnu ti ya ọpọlọpọ eniyan nítorí rẹ̀. Wọ́n bà á lójú jẹ́ yánnayànna, tóbẹ́ẹ̀ tí ìrísí rẹ̀ kò fi jọ ti eniyan mọ́.
15 Bẹ́ẹ̀ ni yóo di ohun ìyanu fún ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè, kẹ́kẹ́ yóo pamọ́ àwọn ọba wọn lẹ́nu, nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn óo rí ohun tí wọn kò gbọ́ rí nípa rẹ̀, òye ohun tí wọn kò mọ̀ rí yóo yé wọn.
1 Ta ló lè gba ìyìn tí a rò gbọ́? Ta ni a ti fi agbára OLUWA hàn?
2 Ó dàgbà níwájú rẹ̀ bí nǹkan ọ̀gbìn tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ rúwé ati bíi gbòǹgbò láti inú ilẹ̀ gbígbẹ. Ìrísí rẹ̀ kò dára, ojú rẹ̀ kò fanimọ́ra, bẹ́ẹ̀ ni kò ní ẹwà tí ìbá fi wu eniyan.
3 Àwọn eniyan kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀; ẹni tí inú rẹ̀ bàjẹ́ tí ó sì mọ ìkáàánú ni. Ó dàbí ẹni tí àwọn eniyan ń wò ní àwòpajúdà. A kẹ́gàn rẹ̀, a kò sì kà á kún.
4 Nítòótọ́, ó ti gbé ìkáàánú wa lọ, ó sì ti ru ìbànújẹ́ wa; sibẹsibẹ a kà á sí ẹni tí a nà, tí a sì jẹ níyà láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun.
5 Ṣugbọn wọ́n ṣá a lọ́gbẹ́ nítorí àìdára wa, wọ́n pa á lára nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa; ìyà tí wọ́n fi jẹ ẹ́ ni ó fún wa ní alaafia, nínà tí a nà án ni ó mú wa lára dá.
6 Gbogbo wa ti ṣáko lọ bí aguntan, olukuluku wa yà sí ọ̀nà tirẹ̀, OLUWA sì ti kó ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo wa lé e lórí.
7 Wọ́n ni í lára, wọ́n pọ́n ọn lójú, sibẹsibẹ kò lanu sọ̀rọ̀, wọ́n fà á lọ bí ọ̀dọ́ aguntan tí wọn ń lọ pa, ati bí aguntan tíí yadi níwájú àwọn tí ń rẹ́ irun rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò lanu sọ̀rọ̀.
8 Wọ́n mú un lọ tipátipá, lẹ́yìn tí wọ́n ti dá a lẹ́jọ́, ta ni ninu ìran rẹ̀ tí ó ṣe akiyesi pé wọ́n ti pa á run lórí ilẹ̀ alààyè, ati pé nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn eniyan mi, ni wọ́n ṣe nà án?
9 Wọ́n tẹ́ ẹ sí ibojì, pẹlu àwọn eniyan burúkú, wọ́n sì sin ín pẹlu ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ṣe ẹnikẹ́ni níbi, kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
10 Sibẹsibẹ, ó wu OLUWA láti pa á lára, ó sì fi í sinu ìbànújẹ́, nígbà tí ó fi ara rẹ̀ rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀; yóo fojú rí ọmọ rẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ yóo sì gùn. Ìfẹ́ OLUWA yóo ṣẹ lọ́wọ́ rẹ̀.
11 Yóo rí èrè àníyàn ọkàn rẹ̀, yóo sì tẹ́ ẹ lọ́rùn; nípa ìmọ̀ rẹ̀ ni iranṣẹ mi, olódodo, yóo dá ọpọlọpọ eniyan láre, yóo sì ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
12 Nítorí náà, n óo fún un ní ìpín, láàrin àwọn eniyan ńlá, yóo sì bá àwọn alágbára pín ìkógun, nítorí pé ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún ikú, wọ́n sì kà á mọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀. Sibẹsibẹ ó ru ẹ̀ṣẹ̀ ọpọlọpọ eniyan, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
1 Máa kọrin! Ìwọ àgàn tí kò bímọ. Máa kọrin sókè, ìwọ tí kò rọbí rí. Nítorí ọmọ ẹni tí ọkọ ṣátì pọ̀, ju ọmọ ẹni tí ń gbé ilé ọkọ lọ, OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.
2 Fẹ ààyè àgọ́ rẹ sẹ́yìn, sì jẹ́ kí aṣọ tí ó ta sórí ibùgbé rẹ gbòòrò sí i, má ṣẹ́wọ́ kù. Na okùn àgọ́ rẹ kí ó gùn, kí o sì kan èèkàn rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí ó lágbára.
3 Nítorí o óo tàn kálẹ̀, sí apá ọ̀tún ati apá òsì, àwọn ọmọ rẹ yóo gba ìtẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọn óo sì máa gbé àwọn ìlú tí ó ti di ahoro.
4 Má bẹ̀rù nítorí ojú kò ní tì ọ́, má sì dààmú, nítorí a kì yóo dójú tì ọ́, nítorí o óo gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe rẹ, o kò sì ní ranti ẹ̀sín ìgbà tí o jẹ́ opó mọ́.
5 Nítorí Ẹlẹ́dàá rẹ ni ọkọ rẹ, OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀. Ẹni Mímọ́ Israẹli ni Olùràpadà rẹ, Ọlọrun gbogbo ayé ni à ń pè é.
6 Nítorí OLUWA ti pè ọ́, bí iyawo tí ọkọ rẹ̀ kọ̀ sílẹ̀, tí ọkàn rẹ̀ bàjẹ́, àní, bí iyawo àárọ̀ ẹni, tí a kọ̀ sílẹ̀; OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.
7 Mo kọ̀ ọ́ sílẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, ṣugbọn n óo kó ọ jọ pẹlu ọpọlọpọ àánú.
8 Mo fojú mi pamọ́ fún ọ, fún ìgbà díẹ̀ nítorí inú mi ń ru sí ọ, ṣugbọn nítorí ìfẹ́ àìlópin mi, n óo ṣàánú fún ọ. Èmi OLUWA, Olùràpadà rẹ ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
9 Bí ìgbà ayé Noa ni Ọ̀rọ̀ yìí rí sí mi: mo búra nígbà náà, pé omi Noa kò ní bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́. Bẹ́ẹ̀ náà ni mo búra nisinsinyii, pé n kò ní bínú sí ọ mọ́, pé n kò ní bá ọ wí mọ́.
10 Bí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ṣí kúrò, tí a sì ṣí àwọn òkè kéékèèké nídìí, ṣugbọn ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀, kò ní yẹ̀ lára rẹ, majẹmu alaafia mi tí mo bá ọ dá kò ní yẹ̀. Èmi OLUWA tí mo ṣàánú fún ọ ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
11 OLUWA ní: “Jerusalẹmu, ìwọ ẹni tí a pọ́n lójú, tí hílàhílo bá, tí a kò sì tù ninu, òkúta tí a fi oríṣìíríṣìí ọ̀dà kùn ni n óo fi kọ́ ọ, òkúta safire ni n óo sì fi ṣe ìpìlẹ̀ rẹ.
12 Òkúta Agate ni n óo fi ṣe ṣóńṣó ilé rẹ, òkúta dídán ni n óo fi ṣe ẹnu ọ̀nà ibodè rẹ, àwọn òkúta olówó iyebíye ni n óo fi mọ odi rẹ.
13 “Gbogbo àwọn ọmọ rẹ ọkunrin, ni OLUWA yóo kọ́ wọn yóo sì ṣe ọpọlọpọ àṣeyọrí.
14 A óo fìdí rẹ múlẹ̀, ninu òdodo, o óo jìnnà sí ìnira, nítorí náà ẹ̀rù kò ní bà ọ́. O óo jìnnà sí ìpayà, nítorí kò ní súnmọ́ ọ.
15 Bí ẹnìkan bá dojú ìjà kọ ọ́, kìí ṣe èmi ni mo rán an, ẹnikẹ́ni tó bá gbéjà kò ọ́, yóo ṣubú nítorí rẹ.”
16 OLUWA ní, “Wò ó! Èmi ni mo dá alágbẹ̀dẹ, tí ó fi ẹwìrì fẹ́ná, tí ó sì rọ àwọn ohun ìjà, fún ìlò rẹ̀, èmi náà ni mo dá apanirun, pé kí ó máa panirun.
17 Kò sí ohun ìjà tí a ṣe láti fi bá ọ jà tí yóo lágbára lórí rẹ. Gbogbo ẹni tí ó bá bá ọ rojọ́ nílé ẹjọ́, ni o óo jàre wọn. Èyí ni ìpín àwọn iranṣẹ OLUWA, ati ìdáláre wọn lọ́dọ̀ mi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
1 OLUWA ní, “Gbogbo ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ, ẹ máa bọ̀ níbi tí omi wà; bí ẹ kò tilẹ̀ lówó lọ́wọ́, ẹ wá ra oúnjẹ kí ẹ sì jẹ. Ẹ wá ra ọtí waini láì mú owó lọ́wọ́, kí ẹ sì ra omi wàrà, tí ẹnikẹ́ni kò díyelé.
2 Kí ló dé tí ẹ̀ ń ná owó yín lórí ohun tí kì í ṣe oúnjẹ? Tí ẹ sì ń ṣe làálàá lórí ohun tí kì í tẹ́ni lọ́rùn? Ẹ fetí sí ọ̀rọ̀ mi dáradára, kí ẹ sì jẹ ohun tí ó dára, ẹ jẹ oúnjẹ aládùn, kí inú yín ó dùn.
3 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, ẹ gbọ́ ohun tí mò ń wí kí ẹ lè yè. N óo ba yín dá majẹmu ayérayé, ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún Dafidi.
4 Wò ó! Mo fi í ṣe olórí fún àwọn eniyan, olórí ati aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè.
5 O óo pe àwọn orílẹ̀-èdè tí o kò mọ̀ rí, àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́ rí yóo sáré wá sọ́dọ̀ rẹ, nítorí OLUWA Ọlọrun rẹ, ati nítorí Ẹni Mímọ́ Israẹli, tí ó ṣe ọ́ lógo.”
6 Ẹ wá OLUWA nígbà tí ẹ lè rí i, ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
7 Kí eniyan burúkú fi ọ̀nà ibi rẹ̀ sílẹ̀, kí alaiṣododo kọ èrò burúkú rẹ̀ sílẹ̀, kí ó yipada sí OLUWA, kí OLUWA lè ṣàánú rẹ̀. Kí ó yipada sọ́dọ̀ Ọlọrun wa, nítorí Ọlọrun yóo dáríjì í lọpọlọpọ.
8 OLUWA ní, “Nítorí èrò tèmi yàtọ̀ sí tiyín, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi yàtọ̀ sí tiyín,
9 Bí ọ̀run ṣe ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín, tí èrò mi sì ga ju èrò yín.
10 “Bí òjò ati yìnyín, tí ń rọ̀ láti ojú ọ̀run, tí wọn kì í pada sibẹ mọ́, ṣugbọn tí wọn ń bomi rin ilẹ̀, tí ń mú kí nǹkan hù jáde; kí àgbẹ̀ lè rí èso gbìn, kí eniyan sì rí oúnjẹ jẹ.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ tó ń jáde lẹ́nu mi yóo rí, kò ní pada sí ọ̀dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣugbọn yóo ṣe ohun tí mo fẹ́ kí ó ṣe, yóo sì ṣe é ní àṣeyọrí.
12 “Nítorí tayọ̀tayọ̀ ni ẹ óo fi máa jáde ní Babiloni, alaafia ni wọ́n óo fi máa sìn yín sọ́nà, òkè ńlá ati kéékèèké yóo máa kọrin níwájú yín. Gbogbo igi inú igbó yóo sì máa pàtẹ́wọ́,
13 igi Sipirẹsi ni yóo máa hù dípò igi ẹlẹ́gùn-ún, igi Mitili ni yóo sì máa hù dípò ẹ̀gún ọ̀gàn, yóo jẹ́ àmì ìrántí fún OLUWA, ati àpẹẹrẹ ayérayé tí a kò ní parẹ́.”
1 OLUWA ní: “Ẹ máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́, kí ẹ sì máa ṣe òdodo; nítorí ìgbàlà mi yóo dé láìpẹ́, ẹ óo sì rí ìdáǹdè mi.
2 Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo ẹni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ati fún ẹni tí ó bá ń tẹ̀lé e, tí ó ń ṣọ́ra, tí kò rú òfin ọjọ́ ìsinmi, tí kò sì fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe nǹkan burúkú.”
3 Kí àjèjì tí ó faramọ́ OLUWA má sọ pé, “Dájúdájú OLUWA yóo yà mí kúrò láàrin àwọn eniyan rẹ̀.” Kí ìwẹ̀fà má sì sọ pé, “Wò ó! Mo dàbí igi gbígbẹ.”
4 Nítorí OLUWA ní, “Bí ìwẹ̀fà kan bá pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí ó bá ṣe ohun tí mo fẹ́, tí ó sì di majẹmu mi mú gbọningbọnin,
5 n óo fún wọn ní ipò láàrin àgbàlá mi, ati ìrántí tí ó dára, ju ọmọkunrin ati ọmọbinrin lọ. Orúkọ tí kò ní parẹ́ laelae, ni n óo fún wọn.
6 “Àwọn àjèjì tí ó bá darapọ̀ mọ́ OLUWA, tí wọn ń sìn ín, tí wọn fẹ́ràn rẹ̀, tí wọn sì ń ṣe iranṣẹ rẹ̀, gbogbo àwọn tí ó bá pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, tí kò sọ ọ́ di ohun ìríra, tí ó sì di majẹmu mi mú gbọningbọnin,
7 n óo mú wọn wá sí orí òkè mímọ́ mi, n óo jẹ́ kí inú wọn máa dùn ninu ilé adura mi. Ọrẹ sísun ati ẹbọ wọn, yóo jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lórí pẹpẹ mi; nítorí ilé adura fún gbogbo eniyan, ni a óo máa pe ilé mi.”
8 OLUWA Ọlọrun tí ń kó àwọn tí ogun túká ní Israẹli jọ sọ pé, “N óo tún kó àwọn mìíràn jọ, kún àwọn tí mo ti kọ́ kó jọ.”
9 Gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti òkèèrè, ẹ máa bọ̀, gbogbo yín ẹ máa bọ̀ bí ẹranko inú ìgbẹ́, ẹ wá jẹ àjẹrun.
10 Afọ́jú ni àwọn aṣọ́de Israẹli gbogbo wọn kò mọ nǹkankan. Ajá tí ó yadi ni wọ́n, wọn kò lè gbó; oorun ni wọ́n fẹ́ràn. Wọn á dùbúlẹ̀, wọn á máa lá àlá.
11 Wọ̀bìà ni wọ́n, alájẹkì, wọn kì í yó. Àwọn olùdarí wọn pàápàá kò mọ nǹkankan. Gbogbo wọn ti tẹ̀ sí ọ̀nà ara wọn, olukuluku wọn ń wá èrè fún ara rẹ̀.
12 Wọn á máa sọ pé: “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á mu waini, ẹ jẹ́ kí á mu ọtí líle ní àmuyó, bí òní ṣe rí ni ọ̀la yóo rí, yóo dùn tayọ.”
1 Olódodo ń ṣègbé, kò sí ẹni tí ó fi ọkàn sí i. A mú àwọn olótìítọ́ kúrò, kò sì sí ẹni tí ó yé, pé à ń yọ olódodo kúrò ninu ìdààmú ni.
2 Àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà òtítọ́, wọn óo wà ní alaafia, wọn óo máa sinmi lórí ibùsùn wọn.
3 Ẹ̀yin ọmọ oṣó wọnyi, ẹ súnmọ́bí fún ìdájọ́, ẹ̀yin ọmọ alágbèrè ati panṣaga.
4 Ta ni ẹ̀ ń fi ṣe ẹlẹ́yà? Ta ni ẹ̀ ń ya ẹnu ní ìyàkuyà sí tí ẹ yọ ṣùtì sí? Ṣebí ọmọ ẹ̀ṣẹ̀ ni yín irú ọmọ ẹ̀tàn;
5 ẹ̀yin tí ẹ kún fún ìṣekúṣe lábẹ́ igi Oaku, ati lábẹ́ gbogbo igi eléwé tútù. Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń pa àwọn ọmọ yín láàrin àfonífojì, ati ní abẹ́ àpáta?
6 Àwọn oriṣa láàrin àwọn òkúta ọ̀bọ̀rọ́, ninu àfonífojì, àwọn ni ẹ̀ ń sìn, àwọn ni ò ń da ẹbọ ohun mímu lé lórí, àwọn ni ò ń fi nǹkan jíjẹ rúbọ sí. Ṣé àwọn nǹkan wọnyi ni yóo mú kí inú mi yọ́?
7 Lórí òkè gíga fíofío, ni o lọ tẹ́ ibùsùn rẹ sí níbẹ̀ ni o tí ń lọ rú ẹbọ.
8 O gbé ère oriṣa kalẹ̀ sí ẹ̀yìn ìlẹ̀kùn ati ẹ̀yìn òpó ìlẹ̀kùn. O kọ̀ mí sílẹ̀, o bọ́ sórí ibùsùn, o tẹ́ ibùsùn tí ó fẹ̀. O wá bá àwọn tí ó wù ọ́ da ọ̀rọ̀ pọ̀, ẹ̀ ń bá ara yín lòpọ̀.
9 O gbọ̀nà, o lọ gbé òróró fún oriṣa Moleki, o kó ọpọlọpọ turari lọ, o rán àwọn ikọ̀ lọ sí ilẹ̀ òkèèrè, o sì ranṣẹ lọ sinu isà òkú pẹlu.
10 Àárẹ̀ mú ọ nítorí ìrìn àjò rẹ jìnnà, sibẹsibẹ o kò sọ fún ara rẹ pé, “Asán ni ìrìn àjò yìí.” Ò ń wá agbára kún agbára, nítorí náà àárẹ̀ kò mú ọ.
11 Ta ni ń já ọ láyà, tí ẹ̀rù rẹ̀ bà ọ́, tí o fi purọ́; tí o kò ranti mi, tí o kò sì ronú nípa mi? Ṣé nítorí mo ti dákẹ́ fún ìgbà pípẹ́, ni o kò fi bẹ̀rù mi?
12 N óo sọ nípa òdodo rẹ ati iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, ṣugbọn wọn kò ní lè ràn ọ́ lọ́wọ́.
13 Nígbà tí o bá kígbe, kí àwọn ère tí o kó jọ gbà ọ́. Atẹ́gùn lásán ni yóo gbé gbogbo wọn lọ Afẹ́fẹ́ ni yóo fẹ́ wọn lọ. Ṣugbọn ẹni tí ó bá sá di mí, ni yóo ni ilẹ̀ náà, òun ni yóo sì jogún òkè mímọ́ mi.
14 OLUWA ní, “Ẹ la ọ̀nà, ẹ la ọ̀nà, ẹ tún ọ̀nà ṣe, ẹ mú gbogbo ohun ìkọsẹ̀ kúrò lọ́nà àwọn eniyan mi.”
15 Nítorí Ẹni Gíga, tí ó ga jùlọ, ẹni tí ń gbé ninu ayérayé, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mímọ́: òun ni ó ní, “Ibi gíga ati mímọ́ ni mò ń gbé lóòótọ́, ṣugbọn mo wà pẹlu àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn ati àwọn onírẹ̀lẹ̀. Láti sọ ọkàn wọn jí.
16 Nítorí n kò ní máa jà títí ayé, tabi kí n máa bínú nígbà gbogbo: nítorí láti ọ̀dọ̀ mi ni ẹ̀mí ti ń jáde, Èmi ni mo dá èémí ìyè.
17 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ojúkòkòrò rẹ̀, inú bí mi, mo jẹ ẹ́ níyà, mo fojú pamọ́, inú sì bí mi; sibẹ ó túbọ̀ ń ṣìnà sí i ni, ó ń ṣe tinú rẹ̀.
18 Mo ti rí bí ó ti ń ṣe, ṣugbọn n óo ṣì wò ó sàn; n óo máa darí rẹ̀, n óo tù ú ninu, n óo sì fún àwọn tí ó bá ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli ní orin ayọ̀.
19 Alaafia ni, alaafia ni fún àwọn tí ó wà ní òkèèrè, ati àwọn tí ó wà nítòsí; n óo sì wò wọ́n sàn.
20 Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú dàbí ríru omi òkun, nítorí òkun kò lè sinmi, omi rẹ̀ a sì máa rú pàǹtí ati ẹrẹ̀ sókè.
21 Kò sí alaafia fún àwọn eniyan burúkú.” Ọlọrun mi ló sọ bẹ́ẹ̀.
1 “Kígbe sókè, má dákẹ́, ké sókè bíi fèrè ogun, sọ ìrékọjá àwọn eniyan mi fún wọn ní àsọyé, sọ ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jakọbu fún wọn.
2 Nítòótọ́ ni wọ́n ń wá mi lojoojumọ, wọ́n sì fẹ́ mọ ìlànà mi, wọ́n ṣe bí orílẹ̀-èdè tí ó mọ òdodo, tí kò kọ òfin Ọlọrun wọn sílẹ̀. Wọ́n ń bèèrè ìdájọ́ òdodo lọ́dọ̀ mi, wọ́n ní ìfẹ́ ati súnmọ́ Ọlọrun.”
3 Wọ́n ń bèèrè pé, “Kí ló dé tí à ń gbààwẹ̀, ṣugbọn tí OLUWA kò rí wa? Tí à ń fìyà jẹ ara wa, ṣugbọn tí kò náání wa?” OLUWA wí pé, “Ìdí rẹ̀ ni pé, nígbà tí ẹ bá ń gbààwẹ̀, ẹ̀ máa ṣe ìfẹ́ ọkàn yín. Ẹ̀ sì máa ni gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ yín lára.
4 Ẹ̀ ń kún fún ìjà ati asọ̀ ní àkókò ààwẹ̀ yín, ẹ̀ ń lu ara yín ní ìlù ìkà. Irú ààwẹ̀ tí ẹ̀ ń gbà yìí kò ní jẹ́ kí Ọlọrun gbọ́ ohùn yín lọ́run.
5 Ṣé irú ààwẹ̀ tí mo yàn nìyí, ọjọ́ tí eniyan yóo rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ lásán? Ṣé kí eniyan lè doríkodò bíi koríko etí odò nìkan ni? Tabi kí ó lè jókòó lórí aṣọ ọ̀fọ̀ ati eérú nìkan? Ṣé èyí ni ẹ̀ ń pè ní ààwẹ̀, ati ọjọ́ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ OLUWA?
6 “Ṣebí irú ààwẹ̀ tí mo yàn ni pé: kí á tú ìdè ìwà burúkú, kí á yọ irin tí a fi di igi àjàgà; kí á dá àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀ lọ́fẹ̀ẹ́, kí á já gbogbo àjàgà?
7 Àní kí ẹ fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, kí ẹ mú àwọn òtòṣì aláìnílé wá sinu ilé yín, bí ẹ bá rí ẹnikẹ́ni ní ìhòòhò, kí ẹ fi aṣọ bò ó, kí ẹ má sì fojú pamọ́ fún ẹni tí ó jẹ́ ẹbí yín.
8 “Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóo tàn bí ìgbà tí ilẹ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ́, ara yín yóo sì tètè yá. Òdodo yín yóo máa tàn níwájú yín. Ògo mi yóo ṣe ààbò lẹ́yìn yín.
9 Ẹ óo ké pè mí nígbà náà, n óo sì da yín lóhùn. Ẹ óo kígbe pè mí, n óo sì dáhùn pé, ‘Èmi nìyí.’ “Bí ẹ bá mú àjàgà kúrò láàrin yín, tí ẹ kò fi ìka gún ara yín nímú mọ́, tí ẹ kò sì sọ ọ̀rọ̀ ibi mọ́.
10 Bí ẹ bá ṣe làálàá láti fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ẹ sì wá ọ̀nà ìtẹ́lọ́rùn fún ẹni tí ìyà ń jẹ, ìmọ́lẹ̀ yín yóo tàn ninu òkùnkùn, òkùnkùn biribiri yín yóo dàbí ọ̀sán.
11 N óo máa tọ yín sọ́nà nígbà gbogbo, n óo fi nǹkan rere tẹ yín lọ́rùn; n óo mú kí egungun yín ó le, ẹ óo sì dàbí ọgbà tí à ń bomi rin, ati bí orísun omi, tí omi rẹ̀ kì í gbẹ.
12 Ẹ óo tún odi yín tí ó ti wó lulẹ̀ mọ, ẹ óo sì gbé àwọn ìpilẹ̀ṣẹ̀ àtijọ́ dìde. Àwọn eniyan yóo máa pè yín ní alátùn-únṣe ibi tí odi ti wó, alátùn-únṣe òpópónà àdúgbò fún gbígbé.
13 “Bí ẹ bá dẹ́kun láti máa ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́, tí ẹ kò sì máa ṣe ìfẹ́ inú yín lọ́jọ́ mímọ́ mi; bí ẹ bá pe ọjọ́ ìsinmi ní ọjọ́ ìdùnnú, tí ẹ pe ọjọ́ mímọ́ OLUWA ní ọjọ́ ológo; bí ẹ bá yẹ́ ẹ sí, tí ẹ kò yà sí ọ̀nà tiyín, tí ẹ kò máa ṣe ìfẹ́ inú ara yín, tabi kí ẹ máa sọ̀rọ̀ àhesọ;
14 nígbà náà ni inú yín yóo máa dùn láti sin èmi OLUWA, n óo gbe yín gun orí òkè ilẹ̀ ayé, n óo sì mu yín jogún Jakọbu, baba ńlá yín. Èmi OLUWA ni ó sọ bẹ́ẹ̀.”
1 Wò ó! Agbára OLUWA kò dínkù, tí ó fi lè gbani là, etí rẹ̀ kò di, tí kò fi ní gbọ́.
2 Ṣugbọn ẹ̀ṣẹ̀ yín ni ó fa ìyapa láàrin ẹ̀yin ati Ọlọrun yín, àìdára yín ni ó mú kí ó fojú pamọ́ fun yín, tí kò fi gbọ́ ẹ̀bẹ̀ yín.
3 Ìpànìyàn ti sọ ọwọ́ yín di aláìmọ́, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀ṣẹ̀, ẹ̀ ń purọ́, ẹ sì ń fi ẹnu yín sọ ọ̀rọ̀ burúkú.
4 Kò sí ẹni tí ó ń pe ẹjọ́ àre, kò sì sí ẹni tí ó ń rojọ́ òdodo. Ẹjọ́ òfo ni ẹ gbójú lé. Ẹ kún fún irọ́ pípa, ìkà ń bẹ ninu yín, iṣẹ́ burúkú sì ń bẹ lọ́wọ́ yín.
5 Ẹ̀ ń bá paramọ́lẹ̀ pa ẹyin rẹ̀, ẹ sì ń ran òwú aláǹtakùn, ẹni tí ó bá jẹ ninu ẹyin yín yóo kú. Bí ẹnìkan bá fọ́ ọ̀kan ninu ẹyin yín, ejò paramọ́lẹ̀ ni yóo jáde sí i.
6 Òwú aláǹtakùn yín kò lè di aṣọ, eniyan kò ní fi iṣẹ́ ọwọ́ yín bora. Iṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ ni iṣẹ́ yín, ìwà ipá sì ń bẹ lọ́wọ́ yín.
7 Ẹsẹ̀ yín yá sí ọ̀nà ibi, ẹ sì yára sí àtipa aláìṣẹ̀. Èrò ẹ̀ṣẹ̀ ni èrò ọkàn yín. Ọ̀nà yín kún fún ìsọdahoro ati ìparun.
8 Ẹ kò mọ ọ̀nà alaafia, kò sí ìdájọ́ òdodo ní ọ̀nà yín. Ẹ ti mú kí ọ̀nà yín wọ́, ẹni tó bá ba yín rìn kò ní ní alaafia.
9 Àwọn eniyan bá dáhùn pé, “Nítorí náà ni ìdájọ́ òtítọ́ fi jìnnà sí wa, tí òdodo kò sì fi dé ọ̀dọ̀ wà. Ìmọ́lẹ̀ ni à ń retí, ṣugbọn òkùnkùn ló ṣú, ìtànṣán oòrùn ni à ń retí, ṣugbọn ìkùukùu ni ó bolẹ̀.
10 À ń táràrà lára ògiri bí afọ́jú, à ń táràrà bí ẹni tí kò lójú. À ń kọsẹ̀ lọ́sàn-án gangan, bí ẹni tí ó jáde ní àfẹ̀mọ́júmọ́ a dàbí òkú láàrin àwọn alágbára.
11 Gbogbo wa ń bú bí ẹranko beari, a sì ń ké igbe ẹ̀dùn bí àdàbà. À ń retí ìdájọ́ òdodo, ṣugbọn kò sí; à ń retí ìgbàlà, ṣugbọn ó jìnnà sí wa.
12 “Nítorí àìdára wa pọ̀ níwájú rẹ, ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí lòdì sí wa; nítorí àwọn àìdára wa wà pẹlu wa, a sì mọ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa:
13 A ń kọjá ààyè wa, à ń sẹ́ OLUWA, a sì ń yipada kúrò ní ọ̀nà Ọlọrun wa. Ọ̀rọ̀ ìninilára ati ọ̀tẹ̀ ni à ń sọ, èrò ẹ̀tàn ní ń bẹ lọ́kàn wa, ọ̀rọ̀ èké sì ní ń jáde lẹ́nu wa.
14 A fi ọwọ́ rọ́ ẹjọ́ ẹ̀tọ́ sẹ́yìn, òdodo sì takété. Òtítọ́ ti ṣubú ní gbangba ìdájọ́, ìdúróṣinṣin kò rọ́nà wọlé.
15 Òtítọ́ di ohun àwátì, ẹni tí ó yàgò fún iṣẹ́ ibi fi ara rẹ̀ fún ayé mú.” OLUWA rí i pé kò sí ìdájọ́ òdodo, ó sì bà á lọ́kàn jẹ́,
16 Ó rí i pé kò sí ẹnìkan tí yóo ṣe onílàjà, ẹnu sì yà á, pé kò sí ẹnìkankan. Ó bá fi ọwọ́ rẹ̀ ṣẹgun fún ara rẹ̀, òdodo rẹ̀ sì gbé e dúró.
17 Ó gbé òdodo wọ̀ bí ìgbàyà, ó fi àṣíborí ìgbàlà borí. Ó gbé ẹ̀san wọ̀ bí ẹ̀wù, ó fi bora bí aṣọ.
18 Yóo san ẹ̀san fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn, yóo bínú sí àwọn tí wọ́n lòdì sí i, yóo sì san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, ati àwọn tí ń gbé erékùṣù.
19 Wọn óo bẹ̀rù orúkọ OLUWA láti ìwọ̀ oòrùn, wọn óo bẹ̀rù ògo rẹ̀ láti ìlà oòrùn; nítorí yóo wá bí ìkún omi, tí ẹ̀fúùfù láti ọ̀dọ̀ OLUWA ń taari.
20 OLUWA ní, “N óo wá sí Sioni bí Olùràpadà, n óo wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Jakọbu, tí wọ́n yipada kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀.
21 “Majẹmu tí Èmi bá wọn dá nìyí: Ẹ̀mí mi tí mo fi le yín lórí, ati ọ̀rọ̀ mi tí mo fi si yín lẹ́nu, kò gbọdọ̀ kúrò lẹ́nu yín, ati lẹ́nu àwọn ọmọ rẹ, ati lẹ́nu arọmọdọmọ yín, láti àkókò yìí lọ ati títí laelae. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
1 Dìde, tan ìmọ́lẹ̀; nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo OLUWA sì ti tàn sára rẹ.
2 Nítorí òkùnkùn yóo bo ayé mọ́lẹ̀, òkùnkùn biribiri yóo sì bo àwọn orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀, ṣugbọn ìmọ́lẹ̀ OLUWA yóo tàn sára rẹ, ògo OLUWA yóo sì hàn lára rẹ.
3 Àwọn orílẹ̀-èdè yóo wá sinu ìmọ́lẹ̀ rẹ, àwọn ọba yóo sì wá sinu ìmọ́lẹ̀ rẹ tí ń tàn.
4 Gbé ojú sókè kí o wò yíká, gbogbo wọn kó ara wọn jọ, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkunrin yóo wá láti òkèèrè, a óo sì gbé àwọn ọmọ rẹ obinrin lé apá wá.
5 Nígbà tí o bá rí wọn, inú rẹ yóo dùn, ara rẹ óo yá gágá. Ọkàn rẹ yóo kún fún ayọ̀, nítorí pé a óo gbé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọrọ̀ inú òkun wá sọ́dọ̀ rẹ. Àwọn orílẹ̀-èdè yóo kó ọrọ̀ wọn wá fún ọ.
6 Ogunlọ́gọ̀ ràkúnmí yóo yí ọ ká, àwọn ọmọ ràkúnmí Midiani ati Efa. Gbogbo àwọn tí wọn wà ní Ṣeba yóo wá, wọn óo mú wúrà ati turari wá; wọn óo sì máa pòkìkí OLUWA.
7 Gbogbo ẹran ọ̀sìn Kedari ni wọ́n óo kó wá fún ọ, wọn óo kó àgbò Nebaiotu wá ta ọ́ lọ́rẹ. Wọn óo jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lórí pẹpẹ mi, ilé mi lógo, ṣugbọn n óo tún ṣe é lógo sí i.
8 Ta ni àwọn wọnyi tí ń fò lọ bí ìkùukùu? Bí ìgbà tí àwọn àdàbà bá ń fò lọ sí ibi ìtẹ́ wọn?
9 Nítorí àwọn erékùṣù yóo dúró dè mí, ọkọ̀ ojú omi Taṣiṣi ni yóo ṣiwaju wọn óo kó àwọn ọmọkunrin rẹ wá láti ilẹ̀ òkèèrè, wọn óo kó wúrà ati fadaka wá pẹlu wọn; nítorí orúkọ OLUWA Ọlọrun rẹ, ati Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí ó ti ṣe ọ́ lógo.
10 OLUWA ní, “Àwọn àjèjì ni yóo máa tún odi rẹ mọ, àwọn ọba wọn yóo sì máa ṣe iranṣẹ fún ọ; nítorí pé inú ló bí mi ni mo fi nà ọ́. Ṣugbọn nítorí ojurere mi ni mo fi ṣàánú fún ọ.
11 Ṣíṣí ni ìlẹ̀kùn rẹ yóo máa wà nígbà gbogbo, a kò ní tì wọ́n tọ̀sán-tòru; kí àwọn eniyan lè máa kó ọrọ̀ orílẹ̀-èdè wá fún ọ, pẹlu àwọn ọba wọn tí wọn yóo máa tì siwaju.
12 Orílẹ̀-èdè tabi ilẹ̀ ọba tí kò bá sìn ọ́ yóo parun, wọn óo di àwópalẹ̀ patapata.
13 “Ògo Lẹbanoni yóo wá sí ọ̀dọ̀ rẹ: igi sipirẹsi, igi firi, ati igi pine; láti bukun ẹwà ilé mímọ́ mi, n óo sì ṣe ibi ìtìsẹ̀ mi lógo.
14 Àwọn ọmọ àwọn tí ń ni ọ́ lára yóo wá, wọn óo tẹríba fún ọ; gbogbo àwọn tí ń kẹ́gàn rẹ, yóo wá tẹríba lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ; wọn óo pè ọ́ ní ìlú OLÚWA, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti kọ̀ ọ́, wọ́n sì kórìíra rẹ, tí kò sí ẹni tí ń gba ààrin rẹ̀ kọjá mọ́, n óo sọ ọ́ di àmúyangàn títí lae; àní, ohun ayọ̀ láti ìrandíran.
16 O óo mu wàrà àwọn orílẹ̀-èdè, o óo mu wàrà àwọn ọba. O óo sì mọ̀ pé èmi OLUWA, ni olùgbàlà rẹ, ati Olùràpadà rẹ, Ẹni Ńlá Jakọbu.
17 “Dípò bàbà, wúrà ni n óo mú wá. Dípò irin, fadaka ni n óo mú wá. Dípò igi, bàbà ni n óo mú wá. Dípò òkúta, irin ni n óo mú wá. N óo mú kí àwọn alabojuto yín wà ní alaafia, àwọn akóniṣiṣẹ́ yín yóo sì máa ṣe òdodo.
18 Kò tún ní sí ìró ìdàrúdàpọ̀ ní ilẹ̀ rẹ mọ́, kò sì ní sí ìdágìrì ati ìparun ní ibodè rẹ, o óo máa pe odi rẹ ní ìgbàlà, o óo sì máa pe ẹnubodè rẹ ní ìyìn.
19 “Kì í ṣe oòrùn ni yóo máa tan ìmọ́lẹ̀ fún ọ mọ́ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe òṣùpá ni yóo máa tan ìmọ́lẹ̀ fún ọ mọ́ ní òru: OLUWA ni yóo máa jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé fún ọ, Ọlọrun rẹ yóo sì jẹ́ ògo rẹ.
20 Oòrùn rẹ kò ní wọ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni òṣùpá rẹ kò ní wọ òkùnkùn. Nítorí OLUWA ni yóo jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé fún ọ, ọjọ́ ọ̀fọ̀ rẹ yóo sì dópin.
21 Gbogbo àwọn eniyan rẹ yóo jẹ́ olódodo, àwọn ni yóo jogún ilẹ̀ náà títí lae. Àwọn ni ẹ̀ka igi tí mo gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, kí á baà lè yìn mí lógo.
22 Ìdílé tí ó rẹ̀yìn jùlọ yóo di orílẹ̀-èdè, èyí tí ó sì kéré jùlọ yóo di orílẹ̀-èdè ńlá, Èmi ni OLUWA, kíákíá ni n óo ṣe é nígbà tí àkókò rẹ̀ bá tó.”
1 Ẹ̀mí OLUWA, Ọlọrun tí bà lé mi, nítorí ó ti fi àmì òróró yàn mí, láti mú ìròyìn ayọ̀ wá fún àwọn tí a ni lára. Ó rán mi pé kí n máa tu àwọn tí ó ní ìbànújẹ́ ninu, kí n máa kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn tí ó wà ní ìgbèkùn, kí n sì máa ṣí ìlẹ̀kùn ọgbà ẹ̀wọ̀n sílẹ̀ fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n.
2 Ó ní kí n máa kéde ọdún ojurere OLUWA, ati ọjọ́ ẹ̀san Ọlọrun wa; kí n sì máa tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ninu.
3 Ó ní kí n máa fún àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Sioni, ní inú dídùn dípò ìkáàánú, kí n fún wọn ní ayọ̀ dípò ìbànújẹ́, kí n jẹ́ kí wọn máa kọrin ìyìn dípò ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn, kí á lè máa pè wọ́n ní igi òdodo, tí OLUWA gbìn, kí á lè máa yìn ín lógo.
4 Wọn óo tún àlàpà ahoro àtijọ́ kọ́, wọn óo tún gbogbo ilé tí ó ti wó lulẹ̀ kọ́, wọn óo sì tún ìlú tí a ti parun láti ọdún gbọọrọ kọ́.
5 Àwọn àjèjì ni yóo máa ba yín bọ́ agbo ẹran yín, àwọn ni yóo sì máa ṣe alágbàṣe ninu ọgbà àjàrà yín;
6 ṣugbọn a óo máa pe ẹ̀yin ní alufaa OLUWA, àwọn eniyan yóo sì máa sọ̀rọ̀ yín bí iranṣẹ Ọlọrun wa. Ẹ̀yin ni ẹ óo máa jẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ọrọ̀ wọn ni ẹ óo sì máa fi ṣògo.
7 Dípò ìtìjú ìpín tiyín yóo jẹ́ meji, dípò àbùkù ẹ óo láyọ̀ ninu ìpín tí ó kàn yín. Ìlọ́po meji ni ìpín yín yóo jẹ́ ninu ilẹ̀ yín, ayọ̀ ayérayé yóo sì jẹ́ tiyín.
8 OLUWA ní, “Nítorí pé mo fẹ́ ẹ̀tọ́, mo sì kórìíra ìfipá jalè ati ohun tí kò tọ́. Dájúdájú n óo san ẹ̀san fún wọn, n óo sì bá wọn dá majẹmu ayérayé.
9 Àwọn ọmọ wọn yóo dá yàtọ̀ láàrin orílẹ̀-èdè, a óo dá arọmọdọmọ wọn mọ̀ láàrin àwọn eniyan, gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn, yóo gbà pé èmi OLUWA ti bukun wọn.”
10 N óo máa yọ̀ ninu OLUWA, ọkàn mi yóo kún fún ayọ̀ sí Ọlọrun mi. Nítorí ó ti fi ìgbàlà wọ̀ mí bí ẹ̀wù, ó sì ti fi òdodo bòmí lára bí aṣọ; bí ọkọ iyawo tí ó ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, ati bí iyawo tí ó ṣe ọ̀ṣọ́ jìngbìnnì.
11 Bí ilẹ̀ tíí mú kí ewéko hù jáde, tí ọgbà sì ń mú kí ohun tí a gbìn sinu rẹ̀ hù, bẹ́ẹ̀ ni OLUWA Ọlọrun yóo mú kí òdodo ati orin ìyìn yọ jáde níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.
1 Nítorí Sioni, ń kò ní dákẹ́, nítorí Jerusalẹmu, ń kò ní sinmi, títí ìdáláre rẹ̀ yóo fi yọ bí ìmọ́lẹ̀, tí ìgbàlà rẹ̀ yóo sì tàn bí àtùpà.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóo rí ìdáláre rẹ, gbogbo ọba ni yóo rí ògo rẹ; orúkọ tuntun, tí OLUWA fúnra rẹ̀ yóo sọ ọ́, ni a óo máa pè ọ́.
3 O óo jẹ́ adé ẹwà lọ́wọ́ OLUWA, ati fìlà oyè lọ́wọ́ Ọlọrun rẹ.
4 A kò ní pè ọ́ ní “Ẹni-tí-a-kọ̀-sílẹ̀” mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní pe ilẹ̀ rẹ ní “Ahoro” mọ́, “Ẹni-OLUWA-fẹ́” ni a óo máa pè ọ́, a óo máa pe ilẹ̀ rẹ ní “Ẹni-a-gbé-níyàwó.” Nítorí pé OLUWA nífẹ̀ẹ́ rẹ, ilẹ̀ rẹ yóo sì dàbí iyawo lójú rẹ̀.
5 Bí ọdọmọkunrin tií nífẹ̀ẹ́ wundia, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkunrin rẹ yóo nífẹ̀ẹ́ rẹ. Bí inú ọkọ iyawo tuntun tíí dùn nítorí iyawo rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni inú Ọlọrun rẹ yóo dùn nítorí rẹ.
6 Jerusalẹmu, mo ti fi àwọn aṣọ́de sí orí odi rẹ; lojoojumọ, tọ̀sán-tòru, wọn kò gbọdọ̀ panumọ́. Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń rán OLUWA létí, ẹ má dákẹ́.
7 Ẹ má jẹ́ kí ó sinmi, títí yóo fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀, títí yóo fi sọ ọ́ di ìlú ìyìn láàrin gbogbo ayé.
8 OLUWA ti fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ búra, ó ti fi agbára rẹ̀ jẹ́ ẹ̀jẹ́, pé òun kò ní fi ọkà oko rẹ, ṣe oúnjẹ fún àwọn ọ̀tá rẹ mọ́; àwọn àjèjì kò sì ní mu ọtí waini rẹ, tí o ṣe wahala lé lórí mọ́.
9 Ṣugbọn àwọn tí ó bá gbin ọkà, ni yóo máa jẹ ẹ́, wọn óo sì máa fìyìn fún OLUWA; àwọn tí ó bá sì kórè àjàrà ni yóo mu ọtí rẹ̀, ninu àgbàlá ilé mímọ́ mi.
10 Ẹ kọjá! Ẹ gba ẹnubodè kọjá, ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn eniyan. Ẹ la ọ̀nà, ẹ la òpópónà, kí ẹ ṣa òkúta kúrò níbẹ̀. Ẹ ta àsíá sókè, fún àwọn eniyan náà.
11 Wò ó! OLUWA ti kéde títí dé òpin ayé. Ó ní, “Ẹ sọ fún àwọn ará Jerusalẹmu pé, ‘Wò ó, olùgbàlà yín ti dé, èrè rẹ wà pẹlu rẹ̀, ẹ̀san rẹ sì wà níwájú rẹ̀.’ ”
12 A óo máa pè yín ní, “Eniyan mímọ́”, “Ẹni-Ìràpadà-OLUWA”. Wọn óo máa pè yín ní, “Àwọn-tí-a-wá-ní-àwárí”; wọn óo sì máa pe Jerusalẹmu ní, “Ìlú tí a kò patì”.
1 “Ta ni ń ti Edomu bọ̀ yìí, tí ó wọ aṣọ àlàárì, tí ń bọ̀ láti Bosira, tí ó yọ bí ọjọ́ ninu aṣọ tí ó wọ̀, tí ń yan bọ̀ ninu agbára ńlá rẹ̀.” “Èmi ni, èmi tí mò ń kéde ẹ̀san, tí mo sì lágbára láti gbani là.”
2 “Kí ló dé tí aṣọ rẹ fi pupa, tí ó dàbí ti ẹni tí ń fún ọtí waini?”
3 OLUWA dáhùn, ó ní, “Èmi nìkan ni mo tí ń fún ọtí waini, ẹnikẹ́ni kò bá mi fún un ninu àwọn eniyan mi. Mo fi ibinu tẹ̀ wọ́n bí èso àjàrà, mo fi ìrúnú tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ wọn bá dà sí mi láṣọ: ó ti di àbààwọ́n sára gbogbo aṣọ mi.
4 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ló wà lọ́kàn mi, ọdún ìràpadà mi sì ti dé.
5 Mo wò yíká, ṣugbọn kò sí olùrànlọ́wọ́, ẹnu yà mí pé, n kò rí ẹnìkan tí yóo gbé mi ró; nítorí náà, agbára mi ni mo fi ṣẹgun, ibinu mi ni ó sì gbé mi ró.
6 Mo fi ibinu tẹ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀, mo fi ìrúnú rọ wọ́n yó, mo sì tú ẹ̀jẹ̀ wọn dà sílẹ̀.”
7 N óo máa sọ nípa ìfẹ́ ńlá OLUWA lemọ́lemọ́, n óo máa kọrin ìyìn rẹ̀; nítorí gbogbo ohun tí OLUWA ti fún wa, ati oore ńlá tí ó ṣe fún ilé Israẹli, tí ó ṣe fún wọn nítorí àánú rẹ̀, ati gẹ́gẹ́ bí ọpọlọpọ ìfẹ́ rẹ̀ tí kìí yẹ̀.
8 OLUWA ní, “Dájúdájú eniyan mi mà ni wọ́n, àwọn ọmọ tí kò ní hùwà àgàbàgebè.” Ó sì di Olùgbàlà wọn.
9 Ninu gbogbo ìyà tí wọ́n jẹ, òun pẹlu wọn ni, angẹli iwájú rẹ̀ sì gbà wọ́n là. Nítorí ìfẹ́ ati àánú rẹ̀, ó rà wọ́n pada. Ó fà wọ́n sókè, ó sì gbé wọn ní gbogbo ìgbà àtijọ́.
10 Ṣugbọn wọ́n hùwà ọlọ̀tẹ̀: wọ́n sì mú Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ bínú. Nítorí náà ó di ọ̀tá wọn, ó sì dojú ìjà kọ wọ́n.
11 Ṣugbọn ó ranti ìgbà àtijọ́, ní àkókò Mose, iranṣẹ rẹ̀. Wọ́n bèèrè pé, ẹni tí ó kó wọn la òkun já dà? Olùṣọ́-aguntan agbo rẹ̀, tí ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrin wọn?
12 Ẹni tí ó gbé agbára rẹ̀ tí ó lógo wọ Mose, tí ó pín òkun níyà níwájú wọn, kí orúkọ rẹ̀ lè lókìkí títí lae.
13 Ó mú wọn la ibú omi kọjá, bí ẹṣin ninu aṣálẹ̀; wọ́n rìn, wọn kò fẹsẹ̀ kọ.
14 Wọ́n rìn wọnú àfonífojì bíi mààlúù, Ẹ̀mí OLUWA sì fún wọn ní ìsinmi. Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe darí àwọn eniyan rẹ̀, kí ó lè gba ògo fún orúkọ rẹ̀.
15 Bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run, láti ibùgbé rẹ mímọ́ tí ó lógo. Ìtara rẹ dà? Agbára rẹ dà? O ti dáwọ́ ìfẹ́ ati àánú rẹ dúró lára wa ni?
16 Ìwọ ni baba wa. Bí Abrahamu kò tilẹ̀ mọ̀ wá, tí Israẹli kò sì dá wa mọ̀. Ìwọ OLUWA ni baba wa, Olùràpadà wa láti ìgbà àtijọ́, ni orúkọ rẹ.
17 OLUWA kí ló dé tí o fi jẹ́ kí á ṣìnà, kúrò lọ́dọ̀ rẹ; tí o sé ọkàn wa lé, tí a kò fi bẹ̀rù rẹ? Pada sọ́dọ̀ wa nítorí àwọn iranṣẹ rẹ, nítorí àwọn ẹ̀yà Israẹli tíí ṣe ìní rẹ.
18 Fún ìgbà díẹ̀, ilé mímọ́ rẹ jẹ́ ti àwa eniyan mímọ́ rẹ; ṣugbọn àwọn ọ̀tá wa ti wó o lulẹ̀.
19 A wá dàbí àwọn tí o kò jọba lórí wọn rí, àní, bí àwọn tí a kò fi orúkọ rẹ pè.
1 Ò bá jẹ́ fa awọsanma ya kí o sì sọ̀kalẹ̀, kí àwọn òkè ńlá máa mì tìtì níwájú rẹ;
2 bí ìgbà tí iná ń jó igbó ṣúúrú, tí iná sì ń mú kí omi hó. Kí orúkọ rẹ di mímọ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè máa gbọ̀n níwájú rẹ!
3 Nígbà tí o bá ṣe nǹkan tí ó bani lẹ́rù, tí ẹnikẹ́ni kò retí, o sọ̀kalẹ̀, àwọn òkè ńlá sì mì tìtì níwájú rẹ.
4 Láti ìgbà àtijọ́, ẹnìkan kò gbọ́ rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò tíì fi ojú rí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn rẹ, tí ń ṣe irú nǹkan wọnyi fún àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
5 Ò máa ran àwọn tí ń fi inú dídùn ṣiṣẹ́ òdodo lọ́wọ́, àwọn tí wọn ranti rẹ ninu ìgbé ayé wọn, o bínú, nítorí náà a dẹ́ṣẹ̀, a ti wà ninu ẹ̀ṣẹ̀ wa tipẹ́. Ǹjẹ́ a óo rí ìgbàlà?
6 Gbogbo wa dàbí aláìmọ́, gbogbo iṣẹ́ òdodo wa dàbí àkísà ẹlẹ́gbin. Gbogbo wa rọ bí ewé, àìdára wa sì ń fẹ́ wa lọ bí atẹ́gùn.
7 Kò sí ẹnìkan tí ń gbadura ní orúkọ rẹ, kò sí ẹni tí ń ta ṣàṣà láti dìmọ́ ọ; nítorí pé o ti fojú pamọ́ fún wa, o sì ti pa wá tì nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa.
8 Sibẹsibẹ OLUWA, ìwọ ni baba wa, amọ̀ ni wá, ìwọ sì ni amọ̀kòkò; iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni gbogbo wa.
9 OLUWA má bínú pupọ jù, má máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ wa títí lae. Jọ̀wọ́, ro ọ̀rọ̀ wa wò, nítorí pé eniyan rẹ ni gbogbo wa.
10 Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀, Sioni ti di aṣálẹ̀, Jerusalẹmu sì ti di ahoro.
11 Wọ́n ti dáná sun ilé mímọ́ wa tí ó lẹ́wà, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́, gbogbo ibi dáradára tí a ní, ló ti di ahoro.
12 OLUWA, ṣé o kò ní ṣe nǹkankan sí ọ̀rọ̀ yìí ni? Ṣé o óo dákẹ́, o óo máa fìyà jẹ wá ni?
1 Mo ṣetán láti mú kí àwọn tí kò bèèrè mi máa wá mi, ati láti fi ara mi han àwọn tí kò wá mi. Mo sọ fún orílẹ̀-èdè tí kì í gbadura ní orúkọ mi pé, “Èmi nìyí, èmi nìyí.”
2 Láti òwúrọ̀ di alẹ́, mo na ọwọ́ mi sí àwọn ọlọ̀tẹ̀ eniyan; àwọn tí wọn ń rìn ní ọ̀nà tí kò dára, tí wọn ń tẹ̀lé èrò ọkàn wọn,
3 tí wọn ń ṣe ohun tí yóo mú mi bínú, níṣojú mi, nígbà gbogbo. Wọ́n ń rúbọ ninu oríṣìíríṣìí ọgbà, wọ́n ń sun turari lórí bíríkì.
4 Àwọn tí wọn ń jókòó sí itẹ́ òkú, tí wọn ń dúró níbi ìkọ̀kọ̀ lóru; àwọn tí wọn ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, tí ìṣaasùn ọbẹ̀ wọn sì kún fún ẹran aláìmọ́.
5 Wọn á máa ké pé, “Yàgò lọ́nà. Má fara kàn mí, nítorí mo jẹ́ ẹni mímọ́ jù ọ́ lọ.” Ṣugbọn bí èéfín ni irú wọn rí ní ihò imú mi, bí iná tí ó ń jó lojoojumọ.
6 Wò ó! A ti kọ ọ́ sílẹ̀ níwájú mi pé, “N kò ní dákẹ́, ṣugbọn n óo gbẹ̀san.
7 N óo gbẹ̀san gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn lára wọn, ati ti àwọn baba wọn. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀. Nítorí pé wọ́n ń sun turari lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń fi mí ṣẹ̀sín lórí àwọn òkè kéékèèké. N óo san ẹ̀san iṣẹ́ wọn àtẹ̀yìnwá fún wọn.
8 “Bí eniyan tíí wòye pé ọtí wà lára ìdì èso àjàrà, tí wọn sìí sọ pé, ‘Ẹ má bà á jẹ́, nítorí ohun rere wà ninu rẹ̀,’ bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe nítorí iranṣẹ mi, n kò ní pa gbogbo wọn run.
9 N óo mú kí arọmọdọmọ jáde lára Jakọbu, àwọn tí yóo jogún òkè ńlá mi yóo sì jáde láti ara Juda. Àwọn tí mo ti yàn ni yóo jogún rẹ̀, àwọn iranṣẹ mi ni yóo sì máa gbé ibẹ̀.
10 Ilé Ṣaroni yóo di ibùjẹ ẹran, àfonífojì Akori yóo sì di ibi tí àwọn ẹran ọ̀sìn yóo máa dùbúlẹ̀ sí, fún àwọn eniyan mi, tí wọ́n wá mi.
11 “Ṣugbọn níti ẹ̀yin tí ẹ kọ mí sílẹ̀, tí ẹ gbàgbé Òkè Mímọ́ mi, tí ẹ tẹ́ tabili sílẹ̀ fún Gadi, oriṣa Oríire, tí ẹ̀ ń po àdàlú ọtí fún Mẹni, oriṣa Àyànmọ́.
12 N óo fi yín fún ogun pa, gbogbo yín ni ẹ óo sì bọ́ sọ́wọ́ àwọn apànìyàn; nítorí pé nígbà tí mo pè yín, ẹ kò dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹ kò gbọ́, ẹ ṣe nǹkan tí ó burú lójú mi; ẹ yan ohun tí inú mi kò dùn sí.
13 Wò ó, àwọn iranṣẹ mi yóo máa rí oúnjẹ jẹ, ṣugbọn ebi yóo máa pa yín; àwọn iranṣẹ mi yóo mu waini, ṣugbọn òùngbẹ yóo máa gbẹ yín. Àwọn iranṣẹ mi yóo máa yọ̀, ṣugbọn ìtìjú yóo máa ba yín.
14 Àwọn iranṣẹ mi yóo máa kọrin nítorí inú wọn dùn, ṣugbọn ẹ̀yin óo máa kígbe oró àtọkànwá; ẹ óo sì máa sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, nítorí àròkàn.
15 Orúkọ tí ẹ óo fi sílẹ̀ fún àwọn àyànfẹ́ mi yóo di ohun tí wọn yóo máa fi gégùn-ún. Èmi Oluwa Ọlọrun óo pa yín. Ṣugbọn n óo pe àwọn iranṣẹ mi ní orúkọ mìíràn.
16 Dé ibi pé ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ tọrọ ibukun ní ilẹ̀ náà, yóo máa tọrọ rẹ̀ ní orúkọ Ọlọrun òtítọ́, ẹnikẹ́ni tí yóo bá sì búra ní ilẹ̀ náà, orúkọ Ọlọrun òtítọ́ ni yóo máa fi búra. Àwọn ìṣòro àtijọ́ yóo ti di ohun ìgbàgbé, a óo sì ti fi wọ́n pamọ́ kúrò níwájú mi.”
17 OLUWA ní, “Mo dá ọ̀run tuntun, ati ayé tuntun; a kò ní ranti àwọn ohun àtijọ́ mọ́, tabi kí wọn sọ sí eniyan lọ́kàn.
18 Ṣugbọn ẹ jẹ́ kí inú yín ó máa dùn, kí ẹ sì máa yọ títí lae, ninu ohun tí mo dá. Wò ó! Mo dá Jerusalẹmu ní ìlú aláyọ̀, mo sì dá àwọn eniyan inú rẹ̀ ní onínú dídùn.
19 N óo láyọ̀ ninu Jerusalẹmu, inú mi óo sì máa dùn sí àwọn eniyan mi. A kò ní gbọ́ igbe ẹkún ninu rẹ̀ mọ́, ẹnikẹ́ni kò sì ní sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn ninu rẹ̀ mọ́.
20 Ọmọ tuntun kò ní kú ní Jerusalẹmu mọ́, àwọn àgbààgbà kò sì ní kú láìjẹ́ pé wọ́n darúgbó kùjọ́kùjọ́. Kàkà bẹ́ẹ̀, ikú ọ̀dọ́ ni a óo máa pe ikú ẹni tí ó bá kú ní ẹni ọgọrun-un ọdún. Bí ẹlẹ́ṣẹ̀ bá kú ní ẹni ọgọrun-un ọdún, a óo sọ pé ó kú ikú ègún.
21 Wọn óo kọ́ ilé, wọn óo gbé inú rẹ̀; wọn óo gbin ọgbà àjàrà, wọn óo sì jẹ èso rẹ̀.
22 Wọn kò ní kọ́lé fún ẹlòmíràn gbé, wọn kò sì ní gbin ọgbà àjàrà fún ẹlòmíràn jẹ. Àwọn eniyan mi yóo pẹ́ láyé bí igi ìrókò, àwọn àyànfẹ́ mi yóo sì jèrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
23 Wọn kò ní ṣe iṣẹ́ àṣedànù, wọn kò ní bímọ fún jamba; nítorí ọmọ ẹni tí OLUWA bukun ni wọn yóo jẹ́, àwọn ati àwọn ọmọ wọn.
24 Kí wọn tó pè mí, n óo ti dá wọn lóhùn, kí wọn tó sọ̀rọ̀ tán, n óo ti gbọ́ ohun tí wọ́n fẹ́ sọ.
25 Ìkookò ati ọmọ aguntan yóo jọ máa jẹ káàkiri; kinniun yóo máa jẹ koríko bíi mààlúù, erùpẹ̀ ni ejò yóo máa jẹ, wọn kò ní máa panilára. Wọn kò sì ní máa panirun lórí òkè mímọ́ mi mọ́. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
1 OLUWA ní: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Ilé tí ẹ kọ́ fún mi dà? Níbo sì ni ibi ìsinmi mi wà?
2 Ọwọ́ mi ni mo fi ṣe gbogbo nǹkan wọnyi, tèmi sì ni gbogbo wọn. Ẹni tí n óo kà kún, ni onírẹ̀lẹ̀ ati oníròbìnújẹ́ eniyan, tí ó ń wárìrì nítorí ọ̀rọ̀ mi.
3 “Ati ẹni tí ó pa mààlúù rúbọ, ati ẹni tí ó pa eniyan; kò sí ìyàtọ̀. Ẹni tí ó fi ọ̀dọ́ aguntan rúbọ, kò yàtọ̀ sí ẹni tí ó lọ́ ajá lọ́rùn pa. Ati ẹni tí ó fi ọkà rúbọ, ati ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ rúbọ, bákan náà ni wọ́n rí. Ẹni tí ó fi turari ṣe ẹbọ ìrántí, kò sì yàtọ̀ sí ẹni tí ó súre níwájú oriṣa. Wọ́n ti yan ọ̀nà tí ó wù wọ́n, wọ́n sì ń fi tọkàntọkàn sin ohun ìríra wọn.
4 Èmi náà óo sì yan ìjìyà fún wọn, n óo jẹ́ kí ẹ̀rù wọn pada sórí wọn. Nítorí pé nígbà tí mo pè wọ́n, ẹnikẹ́ni wọn kò dáhùn; nígbà tí mo sọ̀rọ̀ fún wọn, wọn kò gbọ́, wọ́n ṣe ohun tí ó burú lójú mi, wọ́n yan ohun tí inú mi kò dùn sí.”
5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wárìrì nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arakunrin yín tí wọn kórìíra yín, wọ́n tì yín síta nítorí orúkọ mi; wọ́n ní, ‘Jẹ́ kí OLUWA fi ògo rẹ̀ hàn, kí á lè rí ayọ̀ yín.’ Ṣugbọn àwọn ni ojú yóo tì.
6 Ẹ gbọ́ ariwo ninu ìlú, ẹ gbọ́ ohùn kan láti inú Tẹmpili, ohùn OLUWA ni, ó ń san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
7 “Kí ó tó bẹ̀rẹ̀ sí rọbí, ó ti bímọ. Kí ìrora obí tó mú un, ó ti bí ọmọkunrin kan.
8 Ta ló gbọ́ irú èyí rí? Ta ló rí irú rẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a lè bí ilẹ̀ ní ọjọ́ kan, tabi kí á bí orílẹ̀-èdè kan ní ọjọ́ kan? Ní kété tí Sioni bẹ̀rẹ̀ sí rọbí, ni ó bí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkunrin.
9 Ṣé mo lè jẹ́ kí eniyan máa rọbí, kí n má jẹ́ kí ó bímọ bí? Èmi OLUWA, tí mò ń mú kí eniyan máa bímọ, ṣé, mo jẹ́ sé eniyan ninu?”
10 Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀, kí inú yín dùn nítorí rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀, ẹ bá a yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń ṣọ̀fọ̀ nítorí rẹ̀.
11 Kí ẹ lè mu àmutẹ́rùn, ninu wàrà rẹ̀ tí ń tuni ninu; kí ẹ lè ní ànítẹ́rùn pẹlu ìdùnnú, ninu ọpọlọpọ ògo rẹ̀.
12 Nítorí OLUWA ní: “N óo tú ibukun sórí rẹ̀, bí ìgbà tí odò bá ń ṣàn. N óo da ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́, bí odò tí ò ṣàn kọjá bèbè. Yóo dà yín sẹ́gbẹ̀ẹ́ bí ọmọ tí ń mu ọmú, ẹ óo máa ṣeré lórí orúnkún rẹ̀.
13 N óo rẹ̀ yín lẹ́kún bí ọmọ tí ìyá rẹ̀ rẹ̀ lẹ́kún, bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe tù yín ninu ní Jerusalẹmu.
14 Ẹ óo rí i, inú yín yóo dùn, egungun yín yóo sọjí, bí ìgbà tí koríko bá rúwé. Gbogbo eniyan yóo sì mọ̀ pé ọwọ́ OLUWA wà lára àwọn iranṣẹ rẹ̀, ati pé inú bí i sí àwọn ọ̀tá rẹ̀.”
15 Wò ó! OLUWA ń bọ̀ ninu iná, kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ yóo dàbí ìjì, láti fi ìrúnú san ẹ̀san, yóo sì fi ahọ́n iná báni wí.
16 Nítorí pé iná ni OLUWA yóo fi ṣe ìdájọ́, idà ni yóo fi ṣe ìdájọ́ fún gbogbo eniyan; àwọn tí OLUWA yóo fi idà pa yóo sì pọ̀.
17 OLUWA ní, “Àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀, tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ń lọ bọ̀rìṣà ninu àgbàlá, wọ́n ń jó ijó oriṣa, wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, ati àwọn ohun ìríra, ati èkúté! Gbogbo wọn ni yóo ṣègbé papọ̀.
18 Nítorí mo mọ iṣẹ́ ọwọ́ wọn ati èrò ọkàn wọn. Mò ń bọ̀ wá gbá gbogbo orílẹ̀-èdè ati ẹ̀yà jọ. Nígbà tí wọ́n bá dé, wọ́n óo rí ògo mi.
19 “N óo sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrin wọn. N óo rán àwọn tí ó yè lára wọn sí àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn bíi: Taṣiṣi, Puti, ati Ludi, ilẹ̀ àwọn tafàtafà, ati Tubali ati Jafani, ati àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré; àwọn tí kò tíì gbọ́ òkìkí mi, tí wọn kò sì tíì rí ògo mi rí. Wọn óo sì ròyìn ògo mi láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.
20 Wọn óo sì kó gbogbo àwọn ará yín bọ̀ láti orílẹ̀-èdè gbogbo, wọn óo kó wọn wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fún OLUWA. Wọn óo máa bọ̀ lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́-ogun, lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ati ràkúnmí, wọn óo máa wá sí ìlú Jerusalẹmu, òkè mímọ́ mi, bí àwọn ọmọ Israẹli yóo ti máa mú ẹbọ ohun jíjẹ wọn wá sí ilé OLUWA, ninu àwo tí ó mọ́.
21 N óo mú ninu wọn, n óo fi ṣe alufaa ati ọmọ Lefi.
22 “Bí ọ̀run tuntun ati ayé tuntun tí n óo dá, yóo ṣe máa wà níwájú mi, bẹ́ẹ̀ ni arọmọdọmọ ati orúkọ rẹ̀ yóo máa wà.
23 Láti oṣù tuntun dé oṣù tuntun, ati láti ọjọ́ ìsinmi kan dé ekeji, ni gbogbo eniyan yóo máa wá jọ́sìn níwájú mi. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
24 Wọn óo jáde, wọn óo sì fojú rí òkú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí mi; nítorí ìdin tí ń jẹ wọ́n kò ní kú, bẹ́ẹ̀ ni iná tí ń jó wọn kò ní kú; wọn óo sì jẹ́ ohun ìríra lójú gbogbo eniyan.”