1 Ọkunrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jobu; ó ń gbé ilẹ̀ Usi, ó jẹ́ olódodo ati olóòótọ́ eniyan, ó bẹ̀rù Ọlọrun, ó sì kórìíra ìwà burúkú.
2 Ó bí ọmọkunrin meje ati ọmọbinrin mẹta.
3 Ó ní ẹẹdẹgbaarin (7,000) aguntan, ẹgbẹẹdogun (3,000) ràkúnmí, ẹẹdẹgbẹta (500) àjàgà mààlúù, ẹẹdẹgbẹta (500) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ati ọpọlọpọ iranṣẹ; òun ni ó lọ́lá jùlọ ninu gbogbo àwọn ará ìlà oòrùn.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa lọ jẹ àsè ninu ilé ara wọn. Olukuluku wọn ní ọjọ́ àsè tirẹ̀, wọn a sì máa pe àwọn arabinrin wọn wá sí ilé láti bá wọn jẹ àsè.
5 Nígbà tí wọ́n bá se àsè náà kárí tán, Jobu yóo ranṣẹ sí wọn láti rú ẹbọ ìwẹ̀nùmọ́ fún wọn. Ní àárọ̀ kutukutu, yóo dìde yóo rú ẹbọ sísun fún olukuluku wọn, yóo wí pé, “Bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti bú Ọlọrun ninu ọkàn wọn.” Bẹ́ẹ̀ ni Jobu máa ń ṣe ní gbogbo ìgbà.
6 Ní ọjọ́ kan, àwọn ọmọ Ọlọrun wá láti fi ara wọn hàn níwájú OLUWA. Satani náà wà láàrin wọn.
7 OLUWA bi Satani pé, “Níbo ni o ti ń bọ̀?” Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Mò ń lọ sókè sódò káàkiri gbogbo ayé.”
8 OLUWA tún bi í pé, “Ǹjẹ́ o ṣàkíyèsí Jobu, iranṣẹ mi, pé kò sí ẹni tí ó jẹ́ olóòótọ́ ati eniyan rere bíi rẹ̀ ní gbogbo ayé, ati pé ó bẹ̀rù èmi OLUWA, ó sì kórìíra ìwà burúkú?”
9 Satani dáhùn pé, “Ṣé lásán ni Jobu bẹ̀rù ìwọ Ọlọrun ni?
10 Ṣebí nígbà gbogbo ni ò ń dáàbò bo òun ati àwọn ará ilé rẹ̀, ati gbogbo ohun tí ó ní. Ò ń bukun iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, o sì sọ ohun ìní rẹ̀ di pupọ.
11 Ǹjẹ́, ìwọ mú gbogbo nǹkan wọnyi kúrò wò, o óo rí i pé yóo sọ̀rọ̀ àfojúdi sí ọ lójú ara rẹ.”
12 OLUWA dá Satani lóhùn pé, “Ó dára, ohun gbogbo tí ó ní wà ní ìkáwọ́ rẹ. Ṣugbọn o kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan òun fúnra rẹ̀.” Satani bá kúrò níwájú OLUWA.
13 Ní ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Jobu ń jẹ àsè ninu ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkunrin, tí ó jẹ́ àgbà patapata,
14 iranṣẹ kan wá sọ́dọ̀ Jobu, ó ròyìn fún un pé, “Àwọn akọ mààlúù ń fi àjàgà wọn kọlẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹko nítòsí wọn;
15 àwọn ará Sabea rí wọn, wọ́n sì kó gbogbo wọn, wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn iranṣẹ, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”
16 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ iranṣẹ mìíràn dé, ó ní, “Iná Ọlọrun wá láti ọ̀run, ó jó àwọn aguntan ati gbogbo darandaran patapata, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”
17 Kò tíì dákẹ́ ọ̀rọ̀ tí ń sọ tí iranṣẹ mìíràn fi tún dé, ó ní, “Àwọn ẹgbẹ́ ogun Kalidea mẹta kọlù wá, wọ́n kó gbogbo ràkúnmí wa lọ, wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”
18 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ iranṣẹ mìíràn dé, ó ní, “Bí àwọn ọmọ rẹ tí ń jẹ àsè ninu ilé ẹ̀gbọ́n wọn àgbà,
19 ìjì líle kan fẹ́ la àṣálẹ̀ kọjá, ó fẹ́ lu ilé náà, ó wó, ó sì pa gbogbo wọn, èmi nìkan ni mo sá àsálà láti wá ròyìn fún ọ.”
20 Jobu bá dìde, ó fa aṣọ rẹ̀ ya láti fi ìbànújẹ́ rẹ̀ hàn; ó fá orí rẹ̀, ó dojúbolẹ̀, ó sì sin OLUWA.
21 Ó ní, “Ìhòòhò ni wọ́n bí mi, ìhòòhò ni n óo sì pada lọ. OLUWA níí fún ni ní nǹkan, OLUWA náà ní í sì í gbà á pada, ìyìn ni fún orúkọ OLUWA.”
22 Ninu gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ yìí, Jobu kò dẹ́ṣẹ̀, kò sì dá Ọlọrun lẹ́bi.
1 Nígbà tí ó tún yá tí àwọn ọmọ Ọlọrun wá farahàn níwájú OLUWA, Satani náà wà láàrin wọn.
2 OLUWA tún bi Satani pé, “Níbo ni o ti ń bọ̀?” Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Mò ń lọ sókè sódò káàkiri gbogbo ayé.”
3 Ọlọrun tún bi í pé, “Ǹjẹ́ o ṣàkíyèsí Jobu, iranṣẹ mi, pé kò sí olóòótọ́ ati eniyan rere bíi rẹ̀ ní gbogbo ayé. Ó bẹ̀rù OLUWA, ó sì kórìíra ìwà burúkú, ó dúró ṣinṣin ninu ìwà òtítọ́ rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o dẹ mí sí i láti pa á run láìnídìí.”
4 Satani dá OLUWA lóhùn pé, “Ohun gbogbo ni eniyan lè fi sílẹ̀ láti gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
5 Ìwọ fi ọwọ́ kan ara ati eegun rẹ̀ wò, bí kò bá ní sọ̀rọ̀ àfojúdi sí ọ lójú ara rẹ.”
6 OLUWA bá ní, “Ó wà ní ìkáwọ́ rẹ, ṣugbọn o kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ẹ̀mí rẹ̀.”
7 Satani bá lọ kúrò níwájú OLUWA, ó sì da oówo bo Jobu lára, láti àtẹ́lẹsẹ̀ títí dé orí.
8 Jobu ń fi àpáàdì họ ara, ó sì jókòó sinu eérú.
9 Iyawo Jobu bá sọ fún un pé, “Orí òtítọ́ inú rẹ ni o tún wà sibẹ? Fi Ọlọrun bú, kí o kú.”
10 Ṣugbọn ó dáhùn pé, “Ò ń sọ̀rọ̀ bí ìgbà tí ọ̀kan ninu àwọn aláìmòye obinrin bá ń sọ̀rọ̀. Ǹjẹ́ eniyan lè gba ire lọ́wọ́ Ọlọrun kí ó má gba ibi?” Ninu gbogbo nǹkan wọnyi, Jobu kò dẹ́ṣẹ̀ rárá ninu ọ̀rọ̀ tí ó sọ.
11 Nígbà tí Elifasi ará Temani, Bilidadi ará Ṣuha ati Sofari ará Naama, àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹta, gbọ́ nípa ìyọnu tí ó dé bá Jobu, wọ́n wá láti kí i, ati láti tù ú ninu.
12 Nígbà tí wọ́n rí Jobu ní ọ̀ọ́kán, wọn kò mọ̀ ọ́n mọ́. Ṣugbọn nígbà tí wọ́n súnmọ́ ọn tí wọ́n mọ̀ pé òun ni, wọ́n bú sẹ́kún, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì ku eruku sórí.
13 Wọ́n jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀ pẹlu rẹ̀ fún ọjọ́ meje, tọ̀sán-tòru, láìsọ nǹkankan, nítorí pé wọ́n rí i bí ìrora náà ti pọ̀ tó.
1 Nígbà tí ó yá, Jobu bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, ó fi ọjọ́ ìbí ara rẹ̀ bú.
2 Ó ní:
3 “Ègún ni fún ọjọ́ tí wọ́n bí mi, ati alẹ́ tí wọ́n lóyún mi.
4 Jẹ́ kí ọjọ́ náà ṣókùnkùn biribiri! Kí Ọlọrun má ṣe ka ọjọ́ náà sí, kí ìmọ́lẹ̀ má ṣe tàn sí i mọ́.
5 Ṣe é ní ọjọ́ ìṣúdudu, ati òkùnkùn biribiri. Kí ìkùukùu ṣíji bò ó, kí òkùnkùn sì dẹ́rù bà á.
6 Kí òkùnkùn ṣú bo alẹ́ ọjọ́ náà biribiri, kí á yọ ọ́ kúrò ninu àwọn ọjọ́ tí ó wà ninu ọdún, kí á má sì ṣe kà á kún àwọn ọjọ́ tí wọ́n wà ninu oṣù.
7 Kí alẹ́ ọjọ́ náà di òfo, kí á má ṣe gbọ́ ìró ayọ̀ ninu rẹ̀ mọ́.
8 Kí àwọn tí wọ́n ń fi ọjọ́ gégùn-ún fi gégùn-ún, àní àwọn tí wọ́n lè fi àṣẹ rú Lefiatani sókè.
9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ rẹ̀ ṣókùnkùn, kí ìrètí rẹ̀ fún ìmọ́lẹ̀ àfẹ̀mọ́júmọ́ já sí òfo, kí ó má rí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ mọ́;
10 nítorí pé kò sé inú ìyá mi nígbà tí ó fẹ́ bí mi, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mú ibi kúrò lọ́nà mi.
11 “Kí ló dé tí n kò kú nígbà tí ìyá mi ń rọbí lọ́wọ́, tí ó fẹ́ bí mi, tabi kí n kú, lẹsẹkẹsẹ tí wọ́n bí mi?
12 Kí ló dé tí ìyá mi gbé mi lẹ́sẹ̀? Kí ló dé tí ó fi fún mi lọ́mú?
13 Ǹ bá ti dùbúlẹ̀, ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́; ǹ bá ti sùn, ǹ bá sì ti máa sinmi
14 pẹlu àwọn ọba ati àwọn ìgbìmọ̀ àgbáyé, tí wọ́n ti sùn, àwọn tí wọ́n tún àlàpà kọ́ fún ara wọn;
15 tabi pẹlu àwọn ọmọ aládé tí wọ́n ní wúrà, tí fadaka sì kún ilé wọn.
16 Tabi kí n rí bí ọmọ tí a bí ní ọjọ́ àìpé, tí a bò mọ́lẹ̀ láì tíì lajú sáyé.
17 Níbi tí àwọn oníṣẹ́ ibi kò ti lágbára mọ́, tí àwọn tí gbogbo nǹkan ti sú gbé ń sinmi.
18 Níbẹ̀, àwọn ẹlẹ́wọ̀n ń gbé pọ̀ pẹlu ìrọ̀rùn, wọn kò sì gbọ́ ohùn akóniṣiṣẹ́ mọ́.
19 Àwọn mẹ̀kúnnù ati àwọn eniyan pataki pataki jọ wà níbẹ̀, àwọn ẹrú sì bọ́ lọ́wọ́ oluwa wọn.
20 “Kí ló dé tí a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ń kérora, tí a fi ẹ̀mí fún ẹni tí inú rẹ̀ bàjẹ́;
21 tí ó ń wá ikú, ṣugbọn tí kò rí; tí ó ń wá ikú lójú mejeeji ju ẹni tí ń wá ìṣúra tí a fi pamọ́ lọ?
22 Àwọn tí inú wọn ìbá dùn lọpọlọpọ bí wọ́n bá rí ẹni gbé wọn sin.
23 Kí ló dé tí a fi fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà dàrú mọ́ lójú; ẹni tí Ọlọrun ti tì sinu àhámọ́?
24 Nítorí ìmí ẹ̀dùn di oúnjẹ fún mi, ìráhùn mi sì ń tú jáde bí omi.
25 Ohun tí mo bẹ̀rù jù ti dé bá mi, ohun tí ń fò mí láyà ti ṣẹlẹ̀ sí mi.
26 N kò ní alaafia, bẹ́ẹ̀ ni ara kò rọ̀ mí, n kò sì ní ìsinmi, àfi ìyọnu.”
1 Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:
2 “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀, ṣé kò ní bí ọ ninu? Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?
3 O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan, o ti fún aláìlera lókun.
4 O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró, ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.
5 Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́, o kò ní sùúrù; Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.
6 Ṣé ìbẹ̀rù Ọlọrun kò tó ìgboyà fún ọ? Àbí ìwà òdodo rẹ kò fún ọ ní ìrètí?
7 “Ìwọ náà ronú wò, ṣé aláìṣẹ̀ kan ṣègbé rí? Tabi olódodo kan parun rí?
8 Bí èmi ti rí i sí ni pé, ẹni tí ó kọ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́ ebè, tí ó sì gbin wahala, yóo kórè ìyọnu.
9 Èémí Ọlọrun níí pa wọ́n run, ninu ibinu rẹ̀, wọ́n a sì ṣègbé.
10 Ọlọrun fi òpin sí igbe kinniun, ati bíbú tí kinniun ń bú ramúramù, ó sì wọ́ àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun léyín.
11 Kinniun alágbára a máa kú, nítorí àìrí ẹran pa jẹ, àwọn ọmọ abo kinniun a sì fọ́nká.
12 “Nisinsinyii wọ́n fọ̀rọ̀ kan tó mi létí mo gbọ́ wúyẹ́-wúyẹ́ rẹ̀.
13 Ninu ìran lóru, nígbà tí àwọn eniyan sùn fọnfọn,
14 ìbẹ̀rùbojo mú mi, gbogbo ara mi sì ń gbọ̀n rìrì.
15 Ẹ̀mí kan kọjá fìrí níwájú mi, gbogbo irun ara mi sì dìde.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣugbọn n kò mọ̀ bí ó ti rí. Mo ṣá rí kinní kan tí ó dúró; gbogbo nǹkan parọ́rọ́, nígbà náà ni mo gbọ́ ohùn kan tí ó wí pé,
17 ‘Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun? Tabi kí eniyan jẹ́ mímọ́ níwájú Ẹlẹ́dàá rẹ̀?
18 Nígbà tí ó jẹ́ pé, Ọlọrun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn iranṣẹ rẹ̀, a sì máa bá àṣìṣe lọ́wọ́ àwọn angẹli rẹ̀;
19 mélòó mélòó wá ni eniyan tí a fi amọ̀ mọ, tí ìpìlẹ̀ wọn jẹ́ erùpẹ̀, tí a lè pa bíi kòkòrò lásánlàsàn.
20 Eniyan lè wà láàyè ní òwúrọ̀ kí ó kú kí ó tó di ọjọ́ alẹ́, wọn a parun títí lae láìsí ẹni tí yóo bìkítà.
21 Bí a bá gba gbogbo ohun tí wọ́n fẹ̀mí tẹ̀, ṣé wọn kò ní kú bí aláìgbọ́n?’
1 “Pe ẹnìkan nisinsinyii; ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni dá ọ lóhùn? Ẹni mímọ́ wo ni o lè tọ̀ lọ?
2 Dájúdájú ibinu a máa pa òmùgọ̀, owú jíjẹ a sì máa pa aláìmọ̀kan.
3 Mo ti rí òmùgọ̀ tí ó fìdí múlẹ̀, ṣugbọn lójijì, ibùgbé rẹ̀ di ìfibú.
4 Kò sí ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n di àtẹ̀mọ́lẹ̀ ni ẹnubodè, kò sì sí ẹni tí ó lè gbà wọ́n là.
5 Àwọn tí ebi ń pa níí jẹ ìkórè oko rẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ààrin ẹ̀gún ni ó ti mú un jáde, àwọn olójúkòkòrò a sì máa wá ohun ìní rẹ̀ kiri.
6 Ìṣòro kì í hù láti inú erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìyọnu kì í ti inú ilẹ̀ jáde.
7 A bí eniyan sinu wahala bí ẹ̀ta iná tí ń ta sókè.
8 “Ní tèmi, n óo máa wá OLUWA, n óo fọ̀rọ̀ mi lé Ọlọrun lọ́wọ́;
9 ẹni tíí ṣe ohun ńlá tí eniyan kò lè rídìí, ati àwọn ohun ìyanu tí kò lóǹkà.
10 A máa rọ òjò sórí ilẹ̀, a sì máa bomi rin oko.
11 A máa gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ga, a sì máa pa àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ mọ́.
12 A máa da ète àwọn alárèékérekè rú, kí wọn má baà lè yọrí ètekéte wọn.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n ninu àrékérekè wọn; ó sì mú ète àwọn ẹlẹ́tàn wá sópin.
14 Òkùnkùn bò wọ́n ní ọ̀sán gangan, wọ́n ń fọwọ́ tálẹ̀ lọ́sàn-án bí ẹnipé òru ni.
15 Ṣugbọn Ọlọrun gba aláìníbaba kúrò lọ́wọ́ wọn, ó gba àwọn aláìní kúrò lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Nítorí náà, ìrètí ń bẹ fún talaka, a sì pa eniyan burúkú lẹ́nu mọ́.
17 “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí Ọlọrun bá bá wí, nítorí náà, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olodumare.
18 Ó ń ṣá ni lọ́gbẹ́, ṣugbọn ó tún ń dí ọgbẹ́ ẹni. Ó ń pa ni lára, ṣugbọn ọwọ́ rẹ̀ ló tún fi ń ṣe ìwòsàn.
19 Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ìnira lọpọlọpọ ìgbà, bí ibi ń ṣubú lu ara wọn, kò ní dé ọ̀dọ̀ rẹ.
20 Ní àkókò ìyàn, yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú. Ní àkókò ogun, yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 Yóo gbà ọ́ lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́gàn, o kò ní bẹ̀rù nígbà tí ìparun bá dé.
22 Ninu ìparun ati ìyàn, o óo máa rẹ́rìn-ín, o kò ní bẹ̀rù àwọn ẹranko ìgbẹ́.
23 O kò ní kan àwọn òkúta ninu oko rẹ, àwọn ẹranko igbó yóo wà ní alaafia pẹlu rẹ.
24 O óo máa gbé ilé rẹ ní àìséwu. Nígbà tí o bá ka ẹran ọ̀sìn rẹ, kò ní dín kan.
25 Àwọn arọmọdọmọ rẹ yóo pọ̀, bí ewéko ninu pápá oko.
26 O óo di arúgbó kí o tó kú, gẹ́gẹ́ bí ọkà tií gbó kí á tó kó o wá síbi ìpakà.
27 Wò ó! A ti wádìí àwọn nǹkan wọnyi, òtítọ́ ni wọ́n. Gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ire ara rẹ ni.”
1 Jobu bá dáhùn pé,
2 “Bí ó bá ṣeéṣe láti wọn ìbànújẹ́ mi, tí a bá sì le gbé ìdààmú mi lé orí ìwọ̀n,
3 ìbá wúwo ju yanrìn etí òkun lọ. Ìdí nìyí tí mo fi ń fi ìtara sọ̀rọ̀.
4 Ọfà Olodumare wọ̀ mí lára, oró rẹ̀ sì mú mi. Ọlọrun kó ìpayà bá mi.
5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó a máa ké tí ó bá rí koríko jẹ? Àbí mààlúù a máa dún tí ó bá ń wo oúnjẹ rẹ̀ nílẹ̀?
6 Ǹjẹ́ ohun tí kò dùn ṣe é jẹ láì fi iyọ̀ sí i? Tabi, adùn wo ní ń bẹ ninu funfun ẹyin?
7 Irú oúnjẹ bẹ́ẹ̀ kì í wù mí í jẹ, Ìríra ni jíjẹ rẹ̀ jẹ́ fún mi.
8 “Ìbá ti dára tó, kí Ọlọrun mú ìbéèrè mi ṣẹ, kí ó fún mi ní ohun tí ọkàn mi ń fẹ́.
9 Àní, kí ó wó mi mọ́lẹ̀, kí ó mú mi, kí ó pa mí dànù.
10 Yóo jẹ́ ìtùnú fún mi; n óo sì láyọ̀ ninu ọpọlọpọ ìrora, nítorí pé n kò sẹ́ ọ̀rọ̀ Ẹni Mímọ́.
11 Agbára wo ni mo ní, tí mo fi lè tún máa wà láàyè? Kí sì ni ìrètí mi, tí n óo fi tún máa ní sùúrù?
12 Agbára mi ha rí bí ti òkúta bí? Àbí ẹran ara mi jẹ́ idẹ?
13 Nítòótọ́, n kò ní agbára mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní olùrànlọ́wọ́.
14 “Ẹni tí ó bá kọ̀ tí kò ṣàánú ọ̀rẹ́ rẹ̀ kò ní ìbẹ̀rù Olodumare.
15 Ṣugbọn, ẹ̀yin arakunrin mi, ẹlẹ́tàn ni yín, bíi odò àgbàrá tí ó yára kún, tí ó sì tún yára gbẹ,
16 tí yìnyín bo odò náà tóbẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣókùnkùn, tí yìnyín ńláńlá sì farapamọ́ sibẹ,
17 ṣugbọn ní àkókò ooru, wọn a yọ́, bí ilẹ̀ bá ti gbóná, wọn a sì gbẹ.
18 Àwọn oníṣòwò tí ń lo ràkúnmí yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n ń wá omi kiri wọ́n kiri títí wọ́n fi ṣègbé ninu aṣálẹ̀.
19 Àwọn oníṣòwò Temani ń wò rá rà rá, àwọn ọ̀wọ́ èrò Ṣeba sì dúró pẹlu ìrètí.
20 Ìrètí wọn di òfo nítorí wọ́n ní ìdánilójú. Wọ́n dé ibi tí odò wà tẹ́lẹ̀, ṣugbọn òfo ni wọ́n bá.
21 Bẹ́ẹ̀ ni ẹ rí sí mi nisinsinyii. Ẹ rí ìdààmú mi, ẹ̀rù bà yín.
22 Ǹjẹ́ mo tọrọ ẹ̀bùn lọ́wọ́ yín? Tabi mo bẹ̀ yín pé kí ẹ mú ninu owó yín, kí ẹ fi san àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí mi?
23 Ǹjẹ́ mo bẹ̀ yín pé kí ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá; tabi pé kí ẹ rà mí pada kúrò lọ́wọ́ aninilára?
24 “Ó dára, mo gbọ́, ẹ wá kọ́ mi, ẹ ṣàlàyé ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ fún mi; n óo sì dákẹ́ n óo tẹ́tí sílẹ̀.
25 Lóòótọ́ ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní agbára, ṣugbọn kí ni ẹ̀ ń bá mi wí lé lórí.
26 Ẹ rò pé mò ń fi ọ̀rọ̀ ṣòfò lásán ni? Kí ni ẹ̀ ń dásí ọ̀rọ̀ èmi onírora sí?
27 Ẹ tilẹ̀ lè ṣẹ́ gègé lórí ọmọ òrukàn, ẹ sì lè díye lé ọ̀rẹ́ yín.
28 “Ẹ gbọ́, ẹ wò mí dáradára, nítorí n kò ní purọ́ níwájú yín.
29 Mo bẹ̀ yín, ẹ dúró bẹ́ẹ̀, kí ẹ má baà ṣẹ̀. Ẹ dúró bẹ́ẹ̀, nítorí n kò lẹ́bi.
30 Ṣé ẹ rò pé mò ń parọ́ ni? Àbí n kò mọ nǹkan burúkú yàtọ̀?
1 “Ìgbésí ayé eniyan le koko, ọjọ́ ayé rẹ̀ sì dàbí ti alágbàṣe.
2 Ó dàbí ẹrú tí ń wá ìbòòji kiri ati bí alágbàṣe tí ń dúró de owó iṣẹ́ rẹ̀.
3 Òfo ni ọ̀rọ̀ mi látoṣù-dóṣù, ìbànújẹ́ ní sì ń dé bá mi láti ọjọ́ dé ọjọ́
4 Bí mo bá sùn lóru, n óo máa ronú pé, ‘Ìgbà wo ni ilẹ̀ óo mọ́ tí n óo dìde?’ Òru a gùn bí ẹni pé ojúmọ́ kò ní mọ́ mọ́, ma wá máa yí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, títí ilẹ̀ yóo fi mọ́.
5 Gbogbo ara mi kún fún kòkòrò, ati ìdọ̀tí, gbogbo ara mi yi, ó sì di egbò.
6 Ọjọ́ ayé mi ń sáré ju ọ̀kọ̀ ìhunṣọ lọ, Ó sì ń lọ sópin láìní ìrètí.
7 “Ọlọrun, ranti pé afẹ́fẹ́ lásán ni mo jẹ́, ati pé ojú mi kò ní rí ohun rere mọ́.
8 Ojú ẹni tí ó rí mi nisinsinyii kò ní rí mi mọ́; níṣojú yín báyìí ni n óo fi parẹ́.
9 Bí ìkùukùu tíí parẹ́ tí a kì í rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí tí ó lọ sí ipò òkú rí, kò ní pada mọ́.
10 Kò ní pada sí ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kò ní mọ̀ ọ́n mọ́.
11 “Nítorí náà, n kò ní dákẹ́; n óo sọ ìrora ọkàn mi; n óo tú ìbànújẹ́ mi jáde.
12 Ṣé òkun ni mí ni, tabi erinmi, tí ẹ fi yan olùṣọ́ tì mí?
13 Nígbà tí mo wí pé, ‘Ibùsùn mi yóo tù mí lára, ìjókòó mi yóo sì mú kí ara tù mí ninu ìráhùn mi’.
14 Nígbà náà ni ẹ̀yin tún wá fi àlá yín dẹ́rù bà mí, tí ẹ sì fi ìran pá mi láyà,
15 kí n lè fara mọ́ ọn pé ó sàn kí á lọ́ mi lọ́rùn pa, kí n sì lè yan ikú dípò pé kí n wà láàyè.
16 Ayé sú mi, n kò ní wà láàyè títí lae. Ẹ fi mí sílẹ̀, nítorí ọjọ́ ayé mi dàbí èémí lásán.
17 Kí ni eniyan jẹ́, tí o fi gbé e ga, tí o sì fi ń náání rẹ̀;
18 tí ò ń bẹ̀ ẹ́ wò láràárọ̀, tí o sì ń dán an wò nígbà gbogbo?
19 Yóo ti pẹ́ tó kí ẹ tó mójú kúrò lára mi? Kí ẹ tó fi mí lọ́rùn sílẹ̀ kí n rí ààyè dá itọ́ mì?
20 Bí mo bá ṣẹ̀, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ṣẹ̀ yín, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń ṣọ́ mi? Kí ló dé tí ẹ fi dójú lé mi, tí mo di ẹrù lọ́rùn yín?
21 Kí ló dé tí ẹ kò lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí kí ẹ sì fojú fo àìdára mi? Láìpẹ́ n óo lọ sinu ibojì. Ẹ óo wá mi, ṣugbọn n kò ní sí mọ́.”
1 Bilidadi ará Ṣuha dáhùn pé,
2 “O óo ti sọ irú ọ̀rọ̀ wọnyi pẹ́ tó, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ yóo sì dàbí afẹ́fẹ́ líle?
3 Ṣé Ọlọrun a máa yí ìdájọ́ po? Ṣé Olodumare a máa yí òdodo pada?
4 Bí ó bá jẹ́ pé àwọn ọmọ rẹ dẹ́ṣẹ̀ ni, ó ti jẹ wọ́n níyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
5 Ṣugbọn bí o bá wá Ọlọrun, tí o sì sọ ẹ̀dùn ọkàn rẹ fún Olodumare;
6 tí o bá jẹ́ ẹni mímọ́ ati olóòótọ́, dájúdájú OLUWA yóo dìde, yóo ràn ọ́ lọ́wọ́, yóo sì fi ibùgbé rere san ẹ̀san fún ọ.
7 Díẹ̀ ni ọrọ̀ tí o ní tẹ́lẹ̀ yóo jẹ́ lára ohun tí Ọlọrun yóo fún ọ ní ọjọ́ iwájú.
8 “Mo bẹ̀ ọ́, lọ wádìí nípa ìgbà àtijọ́, kí o ṣe akiyesi ìrírí àwọn baba wa.
9 Nítorí ọmọde ni wá, a kò mọ nǹkankan, ọjọ́ ayé wa sì dàbí òjìji.
10 Àwọn ni wọn óo kọ́ ọ, tí wọn óo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọn óo sì fún ọ ní ìmọ̀ràn ninu òye wọn.
11 “Ṣé koríko etídò le hù níbi tí kò sí àbàtà? Tabi kí èèsún hù níbi tí kò sí omi?
12 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ nígbà tí ó bá ń tanná lọ́wọ́, yóo rọ ṣáájú gbogbo ewéko, láìjẹ́ pé ẹnikẹ́ni gé e lulẹ̀
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbàgbé Ọlọrun rí; ìrètí ẹni tí kò mọ Ọlọrun yóo parun.
14 Igbẹkẹle rẹ̀ já sí asán, ìmúlẹ̀mófo ni, bí òwú aláǹtakùn.
15 Ó farati ilé rẹ̀, ṣugbọn kò le gbà á dúró. Ó dì í mú, ṣugbọn kò lè mú un dúró.
16 Kí oòrùn tó yọ, ẹni ibi a máa tutù yọ̀yọ̀, àwọn ẹ̀ka rẹ̀ a sì gbilẹ̀ káàkiri inú ọgbà rẹ̀.
17 Ṣugbọn ara òkúta ni gbòǹgbò rẹ̀ rọ̀ mọ́, òun gan-an sì ń gbé ààrin àpáta.
18 Bí wọ́n bá fà á tu kúrò ní ààyè rẹ̀, kò sí ẹni tí yóo mọ̀ pé ó wà níbẹ̀ rí.
19 Ayọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ kò jù báyìí lọ, àwọn mìíràn óo dìde, wọn yóo sì gba ipò rẹ̀.
20 “Ṣugbọn Ọlọrun kò jẹ́ fi àwọn olóòótọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò jẹ́ ran ẹni ibi lọ́wọ́.
21 Yóo tún fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́, ẹnu rẹ yóo kún fún ìhó ayọ̀.
22 Ojú yóo ti àwọn ọ̀tá rẹ, ilé àwọn eniyan burúkú yóo sì parẹ́.”
1 Jobu dáhùn pé:
2 “Lóòótọ́, mo mọ̀ pé bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ rí, ṣugbọn báwo ni ẹlẹ́ran ara ṣe lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun?
3 Bí eniyan tilẹ̀ fẹ́ bá a jiyàn, olúwarẹ̀ kò ní lè dáhùn ẹyọ kan ninu ẹgbẹrun ìbéèrè tí yóo bèèrè.
4 Ọgbọ́n rẹ̀ jinlẹ̀, agbára rẹ̀ sì pọ̀. Ta ló tó ṣe oríkunkun sí i kí ó mú un jẹ?
5 Ẹni tí ó ṣí àwọn òkè nídìí, ninu ibinu rẹ̀; tí wọn kò sì mọ ẹni tí ó bì wọ́n ṣubú.
6 Ó ti ayé kúrò ní ipò rẹ̀, àwọn òpó rẹ̀ sì wárìrì.
7 Ó pàṣẹ fún oòrùn, oòrùn kò sì yọ; ó sé àwọn ìràwọ̀ mọ́lé;
8 òun nìkan ṣoṣo ni ó dá ojú ọ̀run tẹ́ bí aṣọ, tí ó sì tẹ ìgbì omi òkun mọ́lẹ̀.
9 Ó dá àwọn ìràwọ̀ sójú ọ̀run: Beari, Orioni, ati Pileiadesi ati àwọn ìràwọ̀ ìhà gúsù.
10 Ó ṣe àwọn ohun ńlá tí ó kọjá òye ẹ̀dá, ati àwọn iṣẹ́ ìyanu tí kò ní òǹkà.
11 Ó gba ẹ̀gbẹ́ mi kọjá, n kò rí i, ó ń kọjá lọ, n kò sì mọ̀.
12 Wò ó! Ó já àwọn ohun tí ó wù ú gbà, ta ló lè dá a dúró? Ta ló tó bi í pé, ‘Kí ni ò ń ṣe?’
13 “Ọlọrun kò ní dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró, yóo fi ẹsẹ̀ tẹ àwọn olùrànlọ́wọ́ Rahabu mọ́lẹ̀.
14 Báwo ni mo ṣe lè bá a rojọ́? Kí ni kí n sọ?
15 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi, sibẹsibẹ n kò lè dá a lóhùn. Ẹ̀bẹ̀ nìkan ni mo lè bẹ̀ fún àánú, lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ẹ̀sùn kàn mí.
16 Bí mo bá pè é pé kó wá gbọ́, tí ó sì dá mi lóhùn, sibẹ n kò lè gbàgbọ́ pé yóo dẹtí sílẹ̀ gbọ́rọ̀ mi.
17 Nítorí pé ó ti fi ìjì tẹ̀ mí mọ́lẹ̀, ó sì sọ egbò mi di pupọ láìnídìí;
18 kò ní jẹ́ kí n mí, ìbànújẹ́ ni ó fi kún ọkàn mi.
19 Bí ó bá ṣe ti pé kí á dán agbára wò ni, agbára rẹ̀ pọ̀ tayọ! Bí ó bá sì jẹ́ pé ti ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́, ta ló lè pè é lẹ́jọ́?
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi, sibẹsibẹ ọ̀rọ̀ ẹnu mi yóo di ẹ̀bi rù mí; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́ṣẹ̀, sibẹsibẹ yóo fihàn pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.
21 N kò lẹ́bi, sibẹ n kò ka ara mi kún, ayé sú mi.
22 Kò sí ìyàtọ̀ lójú rẹ̀, nítorí náà ni mo fi wí pé, ati ẹlẹ́bi ati aláìlẹ́bi ni ó ti parun.
23 Nígbà tí nǹkan burúkú bá ṣẹlẹ̀, tí ó já sí ikú òjijì, a máa fi aláìṣẹ̀ ṣe ẹlẹ́yà ninu ìdààmú wọn.
24 A ti fi ayé lé àwọn ẹni ibi lọ́wọ́, ó ti di àwọn adájọ́ rẹ̀ lójú. Bí kì í bá ṣe òun Ọlọrun, ta ló tún tó bẹ́ẹ̀?
25 “Ọjọ́ ayé mi ń sáré lọ tete, kò sí ẹyọ ọjọ́ kan tí ó dára ninu wọn.
26 Wọ́n sáré kọjá lọ bíi koríko ojú omi, bí ẹyẹ idì tí ń fò fẹ̀ẹ̀ lọ bá ohun tí ó fẹ́ pa.
27 Bí mo bá sọ pé kí n gbàgbé ìráhùn mi, kí n sì tújúká; kí n má ronú mọ́;
28 ẹ̀rù ìrora mi á bẹ̀rẹ̀ sí bà mí, nítorí mo mọ̀ pé o kò ní gbà pé n kò dẹ́ṣẹ̀.
29 Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá mi lẹ́bi, kí ni mo tún ń ṣe wahala lásán fún?
30 Ọṣẹ yòówù tí mo lè fi wẹ̀, kódà kí n fi omi yìnyín fọ ọwọ́,
31 sibẹ o óo tì mí sinu kòtò ìdọ̀tí. Kódà n óo di ohun ìríra sí aṣọ ara mi.
32 Ọlọrun kì í ṣe eniyan bíì mi, tí mo fi lè fún un lésì, tí a fi lè jọ rojọ́ ní ilé ẹjọ́.
33 Kò sí ẹnìkẹta láàrin àwa mejeeji, tí ó lè dá wa lẹ́kun.
34 Kí ó sọ pàṣán rẹ̀ sílẹ̀, kí ó má nà mí mọ́! Kí ìbẹ̀rù rẹ̀ má sì pá mi láyà mọ́!
35 Kí n baà le sọ̀rọ̀ láìbẹ̀rù, nítorí mo mọ inú ara mi.
1 “Ayé sú mi, nítorí náà n kò ní dákẹ́ ìráhùn; n óo sọ̀rọ̀ pẹlu ìbànújẹ́ ọkàn.
2 N óo sọ fún Ọlọrun pé kí ó má dá mi lẹ́bi; kí ó sì jẹ́ kí n mọ ìdí tí ó fi ń bá mi jà.
3 Ṣé ohun tí ó dára ni, Ọlọrun pé kí o máa ni eniyan lára, kí o kórìíra iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, kí o sì fẹ́ràn ète ẹni ibi?
4 Ǹjẹ́ ojú rẹ dàbí ti eniyan? Ǹjẹ́ a máa rí nǹkan bí eniyan ṣe rí i?
5 Ǹjẹ́ bí ọjọ́ ti eniyan ni ọjọ́ rẹ rí? Ǹjẹ́ ọdún rẹ rí bíi ti eniyan?
6 Tí o fi wá ń wádìí àṣìṣe mi, tí o sì ń tanná wá ẹ̀ṣẹ̀ mi?
7 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o mọ̀ pé n kò lẹ́bi, ati pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà mí lọ́wọ́ rẹ.
8 Ọwọ́ rẹ ni o fi dá mi, ọwọ́ kan náà ni o sì tún fẹ́ fi pa mí run.
9 Ranti pé, amọ̀ ni o fi mọ mí, ṣé o tún fẹ́ sọ mí di erùpẹ̀ pada ni?
10 Ṣebí ìwọ ni o dà mí bí omi wàrà, tí o sì ṣù mí pọ̀ bíi wàrà sísè?
11 Ìwọ ni o fi awọ ati ẹran bò mí, tí o rán egungun ati iṣan mi pọ̀.
12 O fún mi ní ìyè, o sì fi ìfẹ́ ńlá rẹ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi, ìtọ́jú rẹ sì ti gbé ẹ̀mí mi ró.
13 Sibẹ o pa gbogbo nǹkan wọnyi mọ́ sọ́kàn rẹ, mo mọ̀ pé èrò ọkàn rẹ ni pé,
14 bí mo bá ṣẹ̀, o óo dójú lé mi, o kò ní jẹ́ kí n lọ láìjìyà.
15 Bí mo bá ṣe àìdára, mo gbé, ṣugbọn bí mo ṣe dáradára, n kò lè yangàn, nítorí ìbànújẹ́ ati ìtìjú bò mí mọ́lẹ̀.
16 Bí mo bá ṣe àṣeyọrí, o óo máa lépa mi bíi kinniun; ò ń lo agbára rẹ láti pa mí lára.
17 O wá àwọn ẹlẹ́rìí tuntun pé kí wọ́n dojú kọ mí, O tún bẹ̀rẹ̀ sí bínú sí mi lọpọlọpọ, O mú kí ogun mìíràn dó tì mí.
18 “Kí ló dé tí o fi mú mi jáde láti inú ìyá mi? Ìbá sàn kí n ti kú, kí ẹnikẹ́ni tó rí mi.
19 Wọn ìbá má bí mi rárá, kí wọ́n gbé mi láti inú ìyá mi lọ sinu ibojì.
20 Ṣebí ọjọ́ díẹ̀ ni mo níláti lò láyé? Fi mí sílẹ̀ kí n lè ní ìtura díẹ̀,
21 kí n tó pada síbi tí mo ti wá, sí ibi òkùnkùn biribiri,
22 ibi òkùnkùn ati ìdàrúdàpọ̀, níbi tí ìmọ́lẹ̀ ti dàbí òkùnkùn.”
1 Sofari ará Naama dáhùn pé,
2 “Ǹjẹ́ ó dára kí eniyan sọ ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ kalẹ̀ báyìí kí ó má sì ìdáhùn? Àbí, ṣé ọ̀pọ̀ ọ̀rọ̀ lè mú kí á dá eniyan láre?
3 Ṣé o rò pé ìsọkúsọ rẹ lè pa eniyan lẹ́nu mọ́ ni? Tabi pé bí o bá ń ṣe ẹlẹ́yà ẹnikẹ́ni kò lè dójútì ọ́?
4 Nítorí o sọ pé ẹ̀kọ́ rẹ tọ̀nà, ati pé ẹni mímọ́ ni ọ́ lójú Ọlọrun.
5 Ọlọrun ìbá ya ẹnu rẹ̀, kí ó sọ̀rọ̀ sí ọ.
6 Kì bá jẹ́ fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́, nítorí ìmọ̀ rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ. Mọ̀ dájú pé ìyà tí Ọlọrun fi jẹ ọ́ kò to nǹkan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
7 “Ǹjẹ́ o lè wádìí àwọn ohun ìjìnlẹ̀ nípa Ọlọrun? Tabi kí o tọpinpin Olodumare?
8 Ó ga ju ọ̀run lọ, kí lo lè ṣe sí i? Ó jìn ju isà òkú lọ, kí lo lè mọ̀ nípa rẹ̀?
9 Ó gùn ju ayé lọ, Ó sì fẹ̀ ju òkun lọ.
10 Tí ó bá ń kọjá lọ, tí ó sì ti eniyan mọ́lé, tí ó pe olúwarẹ̀ lẹ́jọ́, ta ló lè yẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ wò?
11 Nítorí ó mọ àwọn eniyan lásán, ṣé bí ó bá rí ẹ̀ṣẹ̀, kí ó má ṣe akiyesi rẹ̀?
12 Ó di ìgbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ bá bí ọmọ rẹ̀ ní eniyan, kí òmùgọ̀ eniyan tó gbọ́n.
13 “Bí o bá fi ọkàn rẹ sí ohun tí ó tọ́, o óo lè nawọ́ sí i.
14 Bí o bá ń dẹ́ṣẹ̀, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́, má sì ṣe jẹ́ kí ìwà burúkú, wà ní ọwọ́ rẹ.
15 Nígbà náà ni o óo tó lè fi ìgboyà gbójú sókè láìlẹ́bi; o óo wà láìléwu, o kò sì ní bẹ̀rù.
16 O óo gbàgbé àwọn ìyọnu rẹ, nígbà tí o bá sì ranti rẹ̀, yóo dàbí ìkún omi tí ó ti wọ́ lọ.
17 Ayé rẹ yóo mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ; òkùnkùn rẹ yóo sì dàbí òwúrọ̀.
18 Ọkàn rẹ óo balẹ̀, nítorí pé o ní ìrètí, a óo dáàbò bò ọ́, o óo sì sinmi láìséwu.
19 O óo sùn, láìsí ìdágìrì, ọpọlọpọ eniyan ni wọn óo sì máa wá ojurere rẹ.
20 Àwọn ẹni ibi óo pòfo; gbogbo ọ̀nà tí wọ́n lè gbà sá àsálà ni yóo parẹ́ mọ́ wọn lójú, ikú ni yóo sì jẹ́ ìrètí wọn.”
1 Jobu dáhùn pé:
2 “Láìsí àní àní, ẹ̀yin ni agbẹnusọ gbogbo eniyan, bí ẹ bá jáde láyé, ọgbọ́n kan kò tún ní sí láyé mọ́.
3 Bí ẹ ti ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà ní, ẹ kò sàn jù mí lọ. Ta ni kò mọ irú nǹkan, tí ẹ̀ ń sọ yìí?
4 Mo wá di ẹlẹ́yà lójú àwọn ọ̀rẹ́ mi, èmi tí mò ń ké pe Ọlọrun, tí ó sì ń dá mi lóhùn; èmi tí mo jẹ́ olódodo ati aláìlẹ́bi, mo wá di ẹlẹ́yà.
5 Lójú ẹni tí ara tù, ìṣòro kì í báni láìnídìí. Lójú rẹ̀, ẹni tí ó bá ṣìṣe ni ìṣòro wà fún.
6 Àwọn olè ń gbé ilé wọn ní alaafia, àwọn tí wọn ń mú Ọlọrun bínú wà ní àìléwu, àwọn tí ó jẹ́ pé agbára wọn ni Ọlọrun wọn.
7 “Ṣugbọn, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ẹranko, wọn óo sì kọ́ ọ, bi àwọn ẹyẹ, wọn yóo sì sọ fún ọ;
8 tabi kí o bi àwọn koríko, wọn yóo sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóo sì ṣe àlàyé fún ọ.
9 Ta ni kò mọ̀ ninu gbogbo wọn pé OLUWA ló ṣe èyí?
10 Ọwọ́ rẹ̀ ni ìyè gbogbo ẹ̀dá wà, ati ẹ̀mí gbogbo eniyan.
11 Ṣebí etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, ahọ́n a sì máa tọ́ oúnjẹ wò?
12 “Àgbà ló ni ọgbọ́n, àwọn ogbó tí wọ́n ti pẹ́ láyé ni wọ́n ni òye.
13 Ọlọrun ló ni ọgbọ́n ati agbára, tirẹ̀ ni ìmọ̀ràn ati ìmọ̀.
14 Ohun tí Ọlọrun bá wó lulẹ̀, ta ló lè tún un kọ́? Tí ó bá ti eniyan mọ́lé, ta ló lè tú u sílẹ̀?
15 Bí ó bá dáwọ́ òjò dúró, ọ̀gbẹlẹ̀ a dé, bí ó bá sí rọ òjò, omi a bo ilẹ̀.
16 Òun ló ni agbára ati ọgbọ́n, òun ló ni ẹni tí ń tan ni jẹ, òun náà ló ni ẹni tí à ń tàn.
17 Ó pa ọgbọ́n mọ́ àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ninu, ó sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
18 Ó tú àwọn tí àwọn ọba dè mọ́lẹ̀, ó sì so ẹ̀wọ̀n mọ́ àwọn ọba gan-an nídìí.
19 Ó rẹ àwọn alufaa sílẹ̀, ó sì gba agbára lọ́wọ́ àwọn alágbára.
20 Ó pa àwọn agbẹnusọ lẹ́nu mọ́, ó gba ìmọ̀ àwọn àgbààgbà.
21 Ó dójúti àwọn olóyè, ó tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Ó mú ohun òkùnkùn wá sí ìmọ́lẹ̀, ó sì tan ìmọ́lẹ̀ sí òkùnkùn biribiri.
23 Òun níí sọ àwọn orílẹ̀-èdè di ńlá, òun náà níí sìí tún pa wọ́n run: Òun níí kó àwọn orílẹ̀-èdè jọ, òun náà níí sì ń tú wọn ká.
24 Ó gba ìmọ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ìjòyè ní gbogbo ayé, ó sì sọ wọ́n di alárìnká ninu aṣálẹ̀, níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 Wọ́n ń táràrà ninu òkùnkùn, ó sì mú kí wọ́n máa ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n bí ọ̀mùtí.
1 “Gbogbo ìwọ̀nyí ni ojú mi ti rí rí, tí etí mi ti gbọ́, tí ó sì yé mi.
2 Ohun tí ẹ mọ̀ wọnyi, èmi náà mọ̀ ọ́n, ẹ kò sàn jù mí lọ.
3 Ṣugbọn n óo bá Olodumare sọ̀rọ̀, Ọlọrun ni mo sì fẹ́ bá rojọ́.
4 Ẹ̀yin òpùrọ́ ati ẹlẹ́tàn wọnyi, ẹ̀yin oníṣègùn tí ẹ kò lè wonisàn.
5 Ẹ̀ bá jẹ́ pa ẹnu yín mọ́ ni, à bá pè yín ní ọlọ́gbọ́n!
6 Nisinsinyii ẹ gbọ́ èrò ọkàn mi, kí ẹ sì fetísí àròyé mi.
7 Ṣé ẹ óo máa parọ́ ní orúkọ Ọlọrun ni, kí ẹ sì máa sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní orúkọ rẹ̀?
8 Ṣé ẹ fẹ́ máa ṣe ojuṣaaju fún Ọlọrun ni? Tabi ẹ fẹ́ jẹ́ agbẹjọ́rò rẹ̀?
9 Ṣé ẹ óo yege bí ó bá dán yín wò? Tabi ẹ lè tan Ọlọrun bí ẹni tan eniyan?
10 Dájúdájú, yóo ba yín wí, bí ẹ bá ń ṣe ojuṣaaju níkọ̀kọ̀.
11 Ògo rẹ̀ yóo dẹ́rùbà yín, jìnnìjìnnì rẹ̀ yóo dà bò yín.
12 Àwọn òwe yín kò wúlò, àwíjàre yín kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀.
13 Ẹ dákẹ́, kí n ráyè sọ tèmi, kí ohun tí yóo bá dé bá mi dé bá mi.
14 N óo dijú, n óo fi ẹ̀mí ara mi wéwu.
15 Wò ó, yóo pa mí; n kò ní ìrètí; sibẹ n óo wí àwíjàre tèmi níwájú rẹ̀.
16 Èyí ni yóo jẹ́ ìgbàlà mi, nítorí pé ẹni tí kò mọ Ọlọrun, kò ní lè dúró níwájú rẹ̀.
17 Fetí sílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi, kí o sì gbọ́ mi ní àgbọ́yé.
18 Wò ó, mo ti múra ẹjọ́ mi sílẹ̀; mo sì mọ̀ pé n óo gba ìdáláre.
19 Ta ni yóo wá bá mi rojọ́? Bí ó bá wá, n óo dákẹ́, n óo sì kú.
20 Nǹkan meji péré ni mo fẹ́ kí o ṣe fún mi, n kò sì ní farapamọ́ fún ọ:
21 ká ọwọ́ ibinu rẹ kúrò lára mi, má sì ṣe jẹ́ kí jìnnìjìnnì rẹ dà bò mí.
22 Lẹ́yìn náà, sọ̀rọ̀, n óo sì fèsì; tabi kí o jẹ́ kí èmi sọ̀rọ̀, kí o sì fún mi lésì.
23 Báwo ni àìdára ati ẹ̀ṣẹ̀ mi ti pọ̀ tó? Jẹ́ kí n mọ ẹ̀ṣẹ̀ mi, ati ibi tí mo ti kọjá ààyè mi.
24 Kí ló dé tí o fi fi ara pamọ́ fún mi tí o kà mí kún ọ̀tá rẹ?
25 Ṣé o óo máa dẹ́rùba ewé lásán tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ kiri, tabi o óo máa lépa ìyàngbò gbígbẹ?
26 O ti kọ àkọsílẹ̀ burúkú nípa mi, o mú mi jìyà ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi.
27 O kó ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ sí mi lẹ́sẹ̀, ò ń ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ mi, o sì pa ààlà tí n kò gbọdọ̀ rékọjá.
28 Eniyan ń ṣègbé lọ bí ohun tí ó ń jẹrà, bí aṣọ tí ikán ti mu.
1 “Ẹnikẹ́ni tí obinrin bá bí, ọlọ́jọ́ kúkúrú ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.
2 Yóo kọ́ yọ bí òdòdó, lẹ́yìn náà yóo sì rẹ̀ dànù. Yóo kọjá lọ bí òjìji, kò sì ní sí mọ́.
3 Ṣé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni o dojú kọ, tí ò ń bá ṣe ẹjọ́?
4 Ta ló lè mú ohun mímọ́ jáde láti inú ohun tí kò mọ́? Kò sí ẹni náà.
5 Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá ọjọ́ fún un, tí o mọ iye oṣù rẹ̀, tí o sì ti pa ààlà tí kò lè rékọjá.
6 Mú ojú rẹ kúrò lára rẹ̀, kí ó lè sinmi, kí ó sì lè gbádùn ọjọ́ ayé rẹ̀ bí alágbàṣe.
7 “Nítorí pé ìrètí ń bẹ fún igi tí wọn gé, yóo tún pada rúwé, ẹ̀ka rẹ̀ kò sì ní ṣe aláìsọ.
8 Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ògbólógbòó ninu ilẹ̀, tí kùkùté rẹ̀ sì kú,
9 bí ó bá ti gbóòórùn omi, yóo sọ, yóo sì yọ ẹ̀ka bí ọ̀dọ́ irúgbìn.
10 Ṣugbọn bí eniyan bá kú, a óo tẹ́ ẹ sinu ibojì, bí ó bá ti gbẹ́mìí mì, ó di aláìsí.
11 Bí adágún omi tíí gbẹ, ati bí odò tíí ṣàn lọ, tí sìí gbẹ,
12 bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe é sùn, tí kì í sìí jí mọ́, títí tí ọ̀run yóo fi kọjá lọ, kò ní jí, tabi kí ó tilẹ̀ rúnra láti ojú oorun.
13 Ìbá sàn kí o fi mí pamọ́ sinu ibojì, kí o pa mí mọ́ títí inú rẹ yóo fi rọ̀, ò bá dá àkókò fún mi, kí o sì ranti mi.
14 Bí eniyan bá kú, ǹjẹ́ yóo tún jí mọ́? N óo dúró ní gbogbo ọjọ́ làálàá mi, n óo máa retí, títí ọjọ́ ìdáǹdè mi yóo fi dé.
15 O óo pè mí, n ó sì dá ọ lóhùn, o óo máa ṣe àfẹ́rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
16 Nígbà náà, o óo máa tọ́ ìṣísẹ̀ mi, o kò sì ní ṣọ́ àwọn àṣìṣe mi.
17 O óo di àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi sinu àpò, o óo sì bo àwọn àìdára mi mọ́lẹ̀.
18 “Ṣugbọn òkè ńlá ṣubú, ó sì rún wómúwómú, a sì ṣí àpáta nídìí kúrò ní ipò rẹ̀.
19 Bí omi ṣe é yìnrìn òkúta, tí àgbàrá sì í wọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀ lọ, bẹ́ẹ̀ ni o óo ṣe sọ ìrètí eniyan di òfo.
20 O ṣẹgun rẹ̀ títí lae, ó sì kọjá lọ, o yí àwọ̀ rẹ̀ pada, o sì mú kí ó lọ.
21 Wọ́n dá àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́lá, ṣugbọn kò mọ̀, a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, sibẹ kò rí i.
22 Ìrora ara rẹ̀ nìkan ló mọ̀, ọ̀fọ̀ ara rẹ̀ nìkan ni ó ń ṣe.”
1 Elifasi ará Temani bá dáhùn pé,
2 “Ṣé ọlọ́gbọ́n a máa fọ èsì tí kò mọ́gbọ́n lọ́wọ́? Kí ó dàbí àgbá òfìfo?
3 Kí ó máa jiyàn lórí ọ̀rọ̀ tí kò wúlò, tabi ọ̀rọ̀ tí kò níláárí?
4 Ṣugbọn ò ń kọ ìbẹ̀rù Ọlọrun sílẹ̀, o sì ń dènà adura níwájú rẹ̀.
5 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni ó ń fa irú ọ̀rọ̀ tí ń ti ẹnu rẹ jáde, ètè rẹ sì kún fún àrékérekè.
6 Ẹnu rẹ ni ó dá ọ lẹ́bi, kì í ṣe èmi; ẹ̀rí tí ò ń jẹ́ nípa rẹ ní ń ta kò ọ́.
7 “Ṣé ìwọ ni ẹni kinni tí wọ́n kọ́ bí láyé? Tabi o ṣàgbà àwọn òkè?
8 Ṣé o wà ninu ìgbìmọ̀ Ọlọrun? Tabi ìwọ nìkan ni o rò pé o gbọ́n?
9 Kí ni o mọ̀, tí àwa náà kò mọ̀? Òye kí ni o ní, tí ó jẹ́ ohun ìpamọ́ fún àwa?
10 Àwọn tí wọ́n hu ewú lórí wà láàrin wa, ati àwọn àgbàlagbà, àwọn tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 Ṣé ìtùnú Ọlọrun kò tó fún ọ ni, àní ọ̀rọ̀ jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń sọ fún ọ?
12 Àgbéré kí lò ń ṣe, tí o sì ń fi ojú burúkú wò wá.
13 Tí ọkàn rẹ yipada kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun, tí ò ń jẹ́ kí irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ ti ẹnu rẹ jáde?
14 Kí ni eniyan jẹ́, tí ó fi lè mọ́ níwájú Ọlọrun? Kí ni ẹnikẹ́ni tí obinrin bí já mọ́, tí ó fi lè jẹ́ olódodo?
15 Wò ó, Ọlọrun kò fọkàn tán àwọn angẹli, àwọn ọ̀run kò sì mọ́ níwájú rẹ̀.
16 Kí á má tilẹ̀ wá sọ ti eniyan tí ó jẹ́ aláìmọ́ ati ẹlẹ́gbin, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni mu omi!
17 “Fetí sílẹ̀, n óo sọ fún ọ, n óo sọ ohun tí ojú mi rí,
18 (ohun tí àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n sọ, tí àwọn baba wọn kò sì fi pamọ́,
19 àwọn nìkan ni a fún ní ilẹ̀ náà, àlejò kankan kò sì sí láàrin wọn).
20 Ẹni ibi ń yí ninu ìrora ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, àní, ní gbogbo ọdún tí a là sílẹ̀ fún ìkà.
21 Etí rẹ̀ kún fún igbe tí ó bani lẹ́rù, ninu ìdẹ̀ra rẹ̀ àwọn apanirun yóo dìde sí i.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun lè jáde kúrò ninu òkùnkùn; ati pé dájú, ikú idà ni yóo pa òun.
23 Ó ń wá oúnjẹ káàkiri, ó ń bèèrè pé, ‘Níbo ló wà?’ Òun gan-an sì nìyí, oúnjẹ àwọn igún! Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn ti súnmọ́ tòsí.
24 Ìdààmú ati ìrora dẹ́rùbà á, wọ́n ṣẹgun rẹ̀, bí ọba tí ó múra ogun.
25 Nítorí pé ó ṣíwọ́ sókè sí Ọlọrun, o sì ṣe oríkunkun sí Olodumare,
26 ó ń ṣe oríkunkun sí i, ó sì gbé apata tí ó nípọn lọ́wọ́ láti bá a jà;
27 nítorí pé ó sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú rẹ̀ yíbò, ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ sì jẹ́ kìkì ọ̀rá.
28 Ó ń gbé ìlú tí ó ti di ahoro, ninu àwọn ilé tí eniyan kò gbọdọ̀ gbé, àwọn ilé tí yóo pada di òkítì àlàpà.
29 Kò ní ní ọrọ̀, ohun tí ó bá ní, kò ní pẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀, òun alára kò sì ní fìdí múlẹ̀.
30 Kò ní bọ́ kúrò ninu òkùnkùn, iná yóo jó àwọn ẹ̀ka rẹ̀, afẹ́fẹ́ yóo sì fẹ́ àwọn ìtànná rẹ̀ dànù.
31 Kí ó má gbẹ́kẹ̀lé òfo, kí ó má máa tan ara rẹ̀ jẹ, nítorí òfo ni yóo jẹ́ èrè rẹ̀.
32 A ó san án fún un lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ lọ́jọ́ àìpé, gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ ni yóo sì gbẹ.
33 Yóo gbọn àwọn èso rẹ̀ tí kò tíì pọ́n dànù, bí àjàrà, yóo sì gbọn àwọn ìtànná rẹ̀ dànù, bí igi olifi.
34 Nítorí asán ni àwùjọ àwọn tí wọn kò mọ Ọlọ́run, iná yóo sì jó ilé àwọn tí ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Wọ́n ń ro èrò ìkà, wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ibi, wọ́n sì ń pète ẹ̀tàn lọ́kàn.”
1 Jobu bá dáhùn pé,
2 “Èmi náà ti gbọ́ irú nǹkan wọnyi rí, ọlọ́rọ̀ ìtùnú kòbákùngbé ni gbogbo yín.
3 Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ asán tí ẹ̀ ń sọ yìí tilẹ̀ lópin? Àbí, kí ní ń fa gbogbo àríyànjiyàn yìí?
4 Bí ẹ bá wà ní ipò mi, èmi náà lè sọ̀rọ̀ bí ẹ tí ń sọ̀rọ̀ yìí, kí n da ọ̀rọ̀ bò yín, kí n sì máa mi orí si yín.
5 Mo lè fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi fun yín lókun, kí ọ̀rọ̀ ìtùnú mi sì mú kí ara tù yín.
6 “Bí mo sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ kò mú kí ara tù mí, bí mo bá sì dákẹ́, ṣé dídákẹ́ lè tán ìrora mi?
7 Dájúdájú Ọlọrun ti dá mi lágara, ó ti sọ gbogbo ilé mi di ahoro.
8 Híhunjọ tí ara mi hunjọ, jẹ́ ẹ̀rí láti ta kò mí; rírù tí mo rù ta àbùkù mi, ó sì hàn lójú mi.
9 Ó ti fi ibinu fà mí ya, ó sì kórìíra mi; ó pa eyín keke sí mi; ọ̀tá mi sì ń fojú burúkú wò mí.
10 Àwọn eniyan ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n ń gbá mi létí, wọ́n kó ara wọn jọ sí mi.
11 Ọlọrun fà mí lé eniyan burúkú lọ́wọ́, ó mú kí n ṣubú sí ọwọ́ àwọn ìkà.
12 Nígbà tí ó dára fún mi, ó fi ẹ̀yìn mi wọ́nlẹ̀, ó fún mi lọ́rùn, ó gbé mi ṣánlẹ̀, ó sì gbọ̀n mí yẹ́bẹ́yẹ́bẹ́; ó yàn mí sọjú bí àmì ìtafà sí.
13 Àwọn tafàtafà rẹ̀ yí mi ká, ó la kíndìnrín mi láìṣàánú mi, ó sì tú òróòro mi jáde.
14 Ó ń gbógun tì mí nígbà gbogbo, ó pakuuru sí mi bí ọmọ ogun.
15 “Mo fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, mo sùn gbalaja sinu erùpẹ̀.
16 Mo sọkún títí ojú mi fi pọ́n, omijé sì mú kí ojú mi ṣókùnkùn,
17 bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò ṣe ibi, adura mi sì mọ́.
18 “Ìwọ ilẹ̀, má ṣe bo ẹ̀jẹ̀ mi mọ́lẹ̀, má sì jẹ́ kí igbe mi já sí òfo.
19 Nisinsinyii, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ lọ́run, alágbàwí mi sì ń bẹ lókè.
20 Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà, mo sì ń sọkún sí Ọlọrun,
21 ìbá ṣe pé ẹnìkan lè ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọrun, bí eniyan ti lè ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀ níwájú eniyan.
22 Lẹ́yìn ọdún díẹ̀ sí i, n óo lọ àjò àrèmabọ̀.
1 “Ọkàn mi bàjẹ́, ọjọ́ ayé mi ti dópin, ibojì sì ń dúró dè mí.
2 Dájúdájú àwọn ẹlẹ́yà yí mi káàkiri, wọ́n ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ lojukooju.
3 Fi nǹkan ẹ̀jẹ́ kan lélẹ̀ fún mi lọ́dọ̀ rẹ; ta ló wà níbẹ̀ tí yóo ṣe onídùúró fún mi?
4 Níwọ̀n ìgbà tí o ti mú ọkàn wọn yigbì sí ìmọ̀, nítorí náà, o kò ní jẹ́ kí wọ́n borí.
5 Bí ẹnìkan bá hùwà ọ̀dàlẹ̀, tí ó ṣòfófó àwọn ọ̀rẹ́, kí ó lè pín ninu ohun ìní wọn, àwọn ọmọ olúwarẹ̀ yóo jìyà.
6 O ti sọ mí di ẹni àmúpòwe láàrin àwọn eniyan, mo di ẹni tí à ń tutọ́ sí lára.
7 Ìbànújẹ́ sọ ojú mi di bàìbàì, gbogbo ẹ̀yà ara mi dàbí òjìji.
8 Èyí ya àwọn olódodo lẹ́nu, aláìlẹ́bi sì dojú kọ ẹni tí kò mọ Ọlọrun.
9 Sibẹsibẹ olódodo kò fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ mọ́ sì ń lágbára sí i.
10 Ṣugbọn ní tiyín, bí ẹ tilẹ̀ ṣe jù bẹ́ẹ̀ lọ, n kò ní ka ẹnikẹ́ni kún ọlọ́gbọ́n láàrin yín.
11 “Ọjọ́ ayé mi ti dópin, èrò ọkàn mi ti dàrú, àwọn ohun tí ọkàn mi ń fẹ́ sì ti di asán.
12 Wọ́n sọ òru di ọ̀sán, wọ́n ń sọ pé, ‘Ìmọ́lẹ̀ kò jìnnà sí òkùnkùn.’
13 Bí mo bá ní ìrètí pé ibojì yóo jẹ́ ilé mi, tí mo tẹ́ ibùsùn mi sinu òkùnkùn,
14 bí mo bá pe isà òkú ní baba, tí mo sì pe ìdin ní ìyá tabi arabinrin mi,
15 níbo ni ìrètí mi wá wà? Ta ló lè rí ìrètí mi?
16 Ṣé yóo lọ sí ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ ni? Ṣé àwa mejeeji ni yóo jọ wọ inú erùpẹ̀ lọ?”
1 Bilidadi ará Ṣuha bá tún dáhùn pé,
2 “Ìgbàwo ni o óo sinmi ẹjọ́ tí ò ń tò yìí? Ohun tí a tí ń bá ọ sọ ni kí o gbé yẹ̀wò, kí á lè sọ èyí tí a tún fẹ́ sọ.
3 Kí ló dé tí o fi kà wá sí ẹranko, tí a di òmùgọ̀ lójú rẹ?
4 Ìwọ tí o faraya nítorí inú ń bí ọ, ṣé kí á sá kúrò láyé nítorí rẹ ni, tabi kí á ṣí àwọn àpáta nípò pada?
5 “Nítòótọ́, a ti pa fìtílà ẹni ibi, ahọ́n iná rẹ̀ kò sì mọ́lẹ̀ mọ́.
6 Inú àgọ́ rẹ̀ ṣókùnkùn, a sì ti pa àtùpà ìgbèrí rẹ̀.
7 Agbára rẹ̀ ti dín kù, ète rẹ̀ sì gbé e ṣubú.
8 Ó ti ẹsẹ̀ ara rẹ̀ bọ àwọ̀n, ó ń rìn lórí ọ̀fìn.
9 Tàkúté ti mú un ní gìgísẹ̀, ó ti kó sinu pańpẹ́.
10 A dẹ okùn sílẹ̀ fún un, a sì dẹ pańpẹ́ sí ojú ọ̀nà rẹ̀.
11 “Ìbẹ̀rù yí i ká, wọ́n ń lé e kiri.
12 Ebi pa agbára mọ́ ọn ninu, ìṣòro sì ti ṣetán láti gbé e ṣubú.
13 Àìsàn burúkú jẹ awọ ara rẹ̀, àkọ́bí ikú jẹ ẹ́ tọwọ́ tẹsẹ̀.
14 A fipá wọ́ ọ kúrò ninu àgọ́ rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a sì mú un lọ sọ́dọ̀ Ọba Ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀.
15 Àgọ́ rẹ̀ kún fún àwọn tí kì í ṣe tirẹ̀, imí-ọjọ́ fọ́nká sí gbogbo ibùgbé rẹ̀.
16 Gbòǹgbò rẹ̀ gbẹ nísàlẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ sì gbẹ lókè.
17 Ó di ẹni ìgbàgbé lórílẹ̀ ayé, bẹ́ẹ̀ ni a kò gbórúkọ rẹ̀ mọ́ ní ìgboro.
18 Wọ́n tì í láti inú ìmọ́lẹ̀ sinu òkùnkùn, wọ́n lé e kúrò láyé.
19 Kò lọ́mọ, kò lọ́mọ ọmọ, kò sì sí ẹni tí yóo rọ́pò rẹ̀ ní ibùgbé rẹ̀, láàrin àwọn eniyan rẹ̀.
20 Ẹnu yóo ya àwọn ará ìwọ̀ oòrùn, ìwárìrì yóo sì mú àwọn ará ìlà oòrùn, nítorí ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí i.
21 Dájúdájú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé ẹni ibi yóo rí, àní, ilé ẹni tí kò mọ Ọlọrun.”
1 Jobu bá dáhùn, ó ní,
2 “Ẹ óo ti ni mí lára pẹ́ tó, tí ẹ óo máa fi ọ̀rọ̀ yín bà mí ninu jẹ́?
3 Ẹ kẹ́gàn mi ní àìníye ìgbà ojú kò tilẹ̀ tì yín láti ṣẹ̀ mí?
4 Bí ó bá tilẹ̀ jẹ́ pé lótìítọ́ ni mo ṣẹ̀, ṣebí ara mi ni àṣìṣe mi wà?
5 Bí ẹ bá rò pé ẹ sàn jù mí lọ, tí ẹ sì rò pé ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi ni ìdààmú mi,
6 ẹ mọ̀ dájú pé Ọlọrun ni ó dá mi lẹ́bi, tí ó sì fi àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
7 Mò ń kérora pé wọ́n dá mi lóró, ṣugbọn kò sí ẹni tí ó dá mi lóhùn; mo pariwo, pariwo, ṣugbọn kò sí ẹni tí ó dìde láti ṣe ẹ̀tọ́.
8 Ọlọrun ti dí ọ̀nà mọ́ mi, kí n má baà kọjá, ó mú ọ̀nà mi ṣókùnkùn.
9 Ó bọ́ ògo mi kúrò, ó sì gba adé orí mi.
10 Ó ba ayé mi jẹ́ ní gbogbo ọ̀nà, ó sì ti parí fún mi, ó fa ìrètí mi tu bí ẹni fa igi tu.
11 Ibinu rẹ̀ ń jó mi bí iná, ó kà mí kún ọ̀tá rẹ̀.
12 Àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kó ara wọn jọ, wọ́n dó tì mí, wọ́n sì pa àgọ́ tiwọn yí àgọ́ mi ká.
13 “Ó mú kí àwọn arakunrin mi jìnnà sí mi, àwọn ojúlùmọ̀ mi sì di àjèjì sí mi.
14 Àwọn ìyekan mi ati àwọn ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́ ti já mi kulẹ̀.
15 Àwọn àlejò tí wọ́n wọ̀ sí ilé mi ti gbàgbé mi. Àwọn iranṣẹbinrin mi kà mí kún àlejò, wọ́n ń wò mí bí àjèjì.
16 Mo pe iranṣẹ mi, ṣugbọn kò dáhùn, bíbẹ̀ ni mo níláti máa bẹ̀ ẹ́.
17 Mo di ẹni ìríra lọ́dọ̀ iyawo mi, mo sì ń rùn sí àwọn ọmọ ìyá mi.
18 Àwọn ọmọde pàápàá ń fojú tẹmbẹlu mi; bí mo bá dìde wọn á máa sọ̀rọ̀ sí mi.
19 Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́ ti rí mi sá, àwọn tí mo nífẹ̀ẹ́ ti kẹ̀yìn sí mi.
20 Mo rù kan egungun, agbára káká ni mo fi sá àsálà.
21 Ẹ ṣàánú mi, ẹ ṣàánú mi, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọrun ti bà mí!
22 Ọlọrun ń lépa mi, ẹ̀yin náà sì tún ń lépa mi! Kí ló dé tí ẹran ara mi kò to yín?
23 “À bá lè kọ ọ̀rọ̀ mi sílẹ̀! Àní, kí á kọ ọ́ sinu ìwé!
24 Kí á fi kálàmú irin ati òjé kọ ọ́ sórí àpáta, kí ó wà níbẹ̀ títí lae.
25 Ṣugbọn mo mọ̀ pé Olùdáǹdè mi ń bẹ láàyè, ati pé, níkẹyìn, yóo dìde dúró lórí ilẹ̀ yóo sì jẹ́rìí mi,
26 lẹ́yìn tí awọ ara mi bá ti díbàjẹ́, ṣugbọn ninu ara mi ni n óo rí Ọlọ́run.
27 Fúnra mi ni n óo rí i, ojú ara mi ni n óo sì fi rí i, kì í ṣe ti ẹlòmíràn. “Ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì ninu mi!
28 Bí ẹ bá wí pé, ‘Báwo ni a óo ṣe lépa rẹ̀!’ Nítorí pé òun ló jẹ̀bi ọ̀rọ̀ yìí,
29 ṣugbọn, ẹ bẹ̀rù idà, nítorí pé ìrúnú níí fa kí á fi idà pa eniyan, kí ẹ lè mọ̀ dájú pé ìdájọ́ ń bẹ.”
1 Sofari, ará Naama bá dáhùn pé,
2 “Lọ́kàn mi, mo fẹ́ fèsì sí ọ̀rọ̀ rẹ, ara sì ń wá mi, bí ẹni pé kí n dá ọ lóhùn.
3 Mo gbọ́ èébú tí o bú mi, mo sì mọ irú èsì tí ó yẹ kí n fọ̀.
4 Ṣé o kò mọ̀ bẹ́ẹ̀ láti ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí wọ́n ti dá eniyan sórí ilẹ̀ ayé,
5 pé bí inú eniyan burúkú bá ń dùn, tí ẹni tí kò mọ Ọlọrun bá ń yọ̀, fún ìgbà díẹ̀ ni.
6 Bí ìgbéraga rẹ̀ tilẹ̀ ga, tí ó kan ọ̀run, tí orí rẹ̀ kan sánmà,
7 yóo ṣòfò títí lae bí ìgbọ̀nsẹ̀ ara rẹ̀, àwọn tí wọ́n mọ̀ ọ́n yóo bèèrè pé, ‘Níbo ló wà?’
8 Yóo parẹ́ bí àlá, yóo sì di àwátì, yóo pòórá bí ìran tí a rí lóru.
9 Ojú tí ó ti ń rí i tẹ́lẹ̀ kò ní rí i mọ́, ààyè rẹ̀ yóo sì ṣófo.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóo máa wá ojurere àwọn aláìní, wọn yóo sì san ohun tí baba wọn gbà lọ́wọ́ aláìní pada.
11 Bí ó tilẹ̀ dàbí ọ̀dọ́, tí ó lágbára, sibẹ yóo lọ sí ibojì, yóo sì di erùpẹ̀.
12 Bí ọ̀rọ̀ ìkà tilẹ̀ dùn ní ẹnu rẹ̀, tí ó sì fi pamọ́ sí abẹ́ ahọ́n rẹ̀,
13 bí ó tilẹ̀ lọ́ra láti sọ ọ́ jáde, tí ó pa ẹnu mọ́,
14 sibẹsibẹ oúnjẹ rẹ̀ a máa dà á ninu rú, ó sì ti dàbí oró ejò paramọ́lẹ̀ ninu rẹ̀.
15 Gbogbo owó tí ó kó jẹ ni ó tún ń pọ̀ jáde; Ọlọrun ní ń pọ̀ wọ́n jáde ninu ikùn rẹ̀.
16 Yóo mu oró ejò, ahọ́n paramọ́lẹ̀ yóo pa á.
17 Kò ní gbádùn oyin ati wàrà tí ń ṣàn bí odò.
18 Kò ní jẹ èrè wahala rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò ní gbádùn èrè tí ó bá jẹ nídìí òwò rẹ̀.
19 Nítorí pé ó ti tẹ aláìní mọ́lẹ̀, ó sì ti pa wọ́n tì sí apákan ó sì fi ipá gba ilé tí kò kọ́.
20 Nítorí pé oníwọ̀ra ni, tí ọkàn rẹ̀ bá nàró sí nǹkankan, kò lè pa á mọ́ra.
21 Kì í jẹ àjẹṣẹ́kù, nítorí náà, ọlá rẹ̀ kò le tọ́jọ́.
22 Ninu ọlá ńlá rẹ̀ yóo wà ninu àhámọ́, ìbànújẹ́ yóo máa fi tagbára-tagbára bá a jà.
23 Dípò kí ó jẹun ní àjẹyó, ibinu ńlá ni Ọlọrun yóo rán sí i, tí yóo sì dà lé e lórí.
24 Bí ó bá ti ń sá fún idà, bẹ́ẹ̀ ni ọfà bàbà yóo gún un ní àgúnyọ-lódì-keji.
25 Bí ó bá fa ọfà jáde kúrò lára rẹ̀, tí ṣóńṣó orí ọfà jáde láti inú òróòro rẹ̀, ìbẹ̀rùbojo yóo dé bá a.
26 Òkùnkùn biribiri ń dúró dè é, iná tí eniyan kò dá ni yóo jó o ní àjórun, ohun ìní tí ó kù ní ibùgbé rẹ̀ yóo sì parun.
27 Ọ̀run yóo fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn, ilẹ̀ yóo dojú ìjà kọ ọ́.
28 Ibinu Ọlọrun gba àwọn ohun ìní rẹ̀ lọ, àgbàrá ibinu yóo gbá wọn dànù.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ibi yóo rí. Ọlọrun ni ó ti yàn án bẹ́ẹ̀ láti ilẹ̀ wá.”
1 Jobu dáhùn pé,
2 “Ẹ fetí sí ọ̀rọ̀ mi dáradára, kí ẹ sì jẹ́ kí ó jẹ́ ìtùnú fun yín.
3 Ẹ farabalẹ̀, kí ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, lẹ́yìn náà, ẹ lè máa fi mí ṣẹ̀sín ǹṣó.
4 Ṣé eniyan ni mò ń bá rojọ́ ni? Kí ló dé tí n óo fi mú sùúrù?
5 Ẹ wò mí, kí ẹnu yà yín, kí ẹ sì fọwọ́ bo ẹnu.
6 Nígbà tí mo ro ohun tí ó dé bá mi, ẹ̀rù bà mí, mo sì wárìrì.
7 Kí ló dé tí eniyan burúkú fi wà láàyè, tí ó di arúgbó, tí ó sì di alágbára?
8 Àwọn ọmọ wọn ati arọmọdọmọ wọn di eniyan pataki pataki lójú ayé wọn.
9 Kò sí ìfòyà ninu ilé wọn, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọrun kò jẹ wọ́n níyà.
10 Àwọn mààlúù wọn ń gùn, wọ́n sì ń bímọ ní àbíyè.
11 Wọn a máa kó àwọn ọmọ wọn jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa ṣe àríyá.
12 Wọn a máa fi aro, ìlù, ati fèrè kọrin, wọn a sì máa yọ̀ sí ohùn dùùrù.
13 Wọn a máa gbé inú ọlá, wọn a sì máa kú ikú alaafia.
14 Wọ́n ń sọ fún Ọlọrun pé, ‘Fi wá sílẹ̀! A kò fẹ́ mọ òfin rẹ.
15 Ta ni Olodumare, tí a óo fi máa sìn ín? Èrè wo ni ó wà níbẹ̀ fún wa bí à ń gbadura sí i?’
16 Wọ́n rò pé ìkáwọ́ wọn ni ọlà wọn wà, nítèmi n kò lè tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú.
17 “Ìgbà mélòó ni à ń pa fìtílà ẹni ibi? Ìgbà mélòó ni iṣẹ́ ibi wọn ń dà lé wọn lórí? Tabi tí Ọlọrun ṣe ìpín wọn ní ìrora ninu ibinu rẹ̀?
18 Ìgbà mélòó ni wọ́n dàbí àgékù koríko, tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ kiri, tabi bí ìyàngbò tí ìjì ń gbé lọ?
19 “O ní, ‘Ọlọrun ń to àìdára wọn jọ de àwọn ọmọ wọn.’ Jẹ́ kí ó dà á lé wọn lórí, kí wọ́n baà lè mọ ohun tí wọ́n ṣe.
20 Jẹ́ kí wọ́n fi ojú ara wọn rí ìparun ara wọn, kí wọ́n sì rí ibinu Olodumare.
21 Kí ni ó kàn wọ́n pẹlu ilé wọn mọ́, lẹ́yìn tí wọn bá ti kú, nígbà tí a bá ti ké ọjọ́ wọn kúrò lórí ilẹ̀.
22 Ṣé ẹnìkan lè kọ́ Ọlọrun ní ìmọ̀, nígbà tí ó jẹ́ pé òun ni onídàájọ́ àwọn tí wọ́n wà ní ibi gíga?
23 Ẹnìkan kú ninu ọpọlọpọ ọrọ̀, nítorí pé ó wà ninu ìdẹ̀ra ati àìfòyà,
24 ara rẹ̀ ń dán fún sísanra, ara sì tù ú dé mùdùnmúdùn.
25 Ẹlòmíràn kú pẹlu ìbànújẹ́ ọkàn, láìtọ́ ohun rere kankan wò rí.
26 Bákan náà ni gbogbo wọn ṣe sùn ninu erùpẹ̀, tí ìdin sì bò wọ́n.
27 “Wò ó! Mo mọ èrò ọkàn yín, mo sì mọ ète tí ẹ ní sí mi láti ṣe mí níbi.
28 Nítorí ẹ wí pé, ‘Níbo ni ilé àwọn eniyan ńlá wà; níbo sì ni àgọ́ àwọn aṣebi wà?’
29 Ṣé ẹ kò tíì bèèrè ọ̀nà lọ́wọ́ àwọn arìnrìnàjò? Ṣé ẹ kò sì tíì gba ẹ̀rí wọn, pé,
30 a dá ẹni ibi sí ní ọjọ́ ìdàrúdàpọ̀, ati pé a gbà á là ní ọjọ́ ibinu?
31 Kò sẹ́ni tó jẹ́ fẹ̀sùn kan ẹni ibi lójú rẹ̀, tabi kí ó gbẹ̀san nǹkan burúkú tí ó ṣe.
32 Nígbà tí a bá gbé e lọ sí itẹ́, àwọn olùṣọ́ a máa ṣọ́ ibojì rẹ̀.
33 Ẹgbẹẹgbẹrun èrò a tẹ̀lé e lọ sí ibojì, àìmọye eniyan a sì sin òkú rẹ̀; kódà, ilẹ̀ á dẹ̀ fún un ní ibojì rẹ̀.
34 Nítorí náà, kí ni ìsọkúsọ tí ẹ lè fi tù mí ninu? Kò sóhun tó kù ninu ọ̀rọ̀ yín, tó ju irọ́ lọ.”
1 Elifasi ará Temani bá dáhùn pé,
2 “Ǹjẹ́ eniyan lè wúlò fún Ọlọrun? Nítòótọ́, bí eniyan tilẹ̀ jẹ́ ọlọ́gbọ́n, ara rẹ̀ ni ó wúlò fún.
3 Ǹjẹ́ jíjẹ́ olódodo rẹ̀ ṣe ohun rere kan fún Olodumare, tabi kí ni èrè rẹ̀ bí ó bá jẹ́ ẹni pípé?
4 Ṣé nítorí pé o bẹ̀rù rẹ̀ ni ó ṣe bá ọ wí, tí ó sì ń dá ọ lẹ́jọ́?
5 Ṣebí ìwà ibi rẹ ló pọ̀; tí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lópin?
6 O gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ àwọn arakunrin rẹ láìnídìí, O bọ́ wọn sí ìhòòhò goloto.
7 O kò fún aláàárẹ̀ ní omi mu, o kọ̀ láti fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ.
8 Ẹni tí ó lágbára gba ilẹ̀, ẹni tí ó lọ́lá sì ń gbé inú rẹ̀.
9 O lé àwọn opó jáde lọ́wọ́ òfo, o sì ṣẹ́ aláìní baba lápá.
10 Nítorí náà ni okùn dídẹ fi yí ọ ká, tí jìnnìjìnnì sì bò ọ́ lójijì.
11 Ìmọ́lẹ̀ rẹ ti di òkùnkùn, o kò ríran, ìgbì omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 “Ṣebí Ọlọrun wà lókè ọ̀run Ó ń wo àwọn ìràwọ̀ nísàlẹ̀ àní àwọn tí wọ́n ga jùlọ, bí ó ti wù kí wọ́n ga tó!
13 Sibẹsibẹ ò ń bèèrè pé, ‘Kí ni Ọlọrun mọ̀?’ Ṣé ó lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn biribiri?
14 Ìkùukùu tí ó nípọn yí i ká, tóbẹ́ẹ̀ tí kò lè ríran, ó sì ń rìn ní òfuurufú ojú ọ̀run.
15 “Ṣé ọ̀nà àtijọ́ ni ìwọ óo máa tẹ̀lé; ọ̀nà tí àwọn ẹni ibi rìn?
16 A gbá wọn dànù, kí àkókò wọn tó tó, a ti gbá ìpìlẹ̀ wọn lọ.
17 Wọ́n sọ fún Ọlọrun pé, ‘Fi wá sílẹ̀, kí ni ìwọ Olodumare lè fi wá ṣe?’
18 Sibẹsibẹ ó fi ìṣúra dáradára kún ilé wọn– ṣugbọn ìmọ̀ràn ẹni ibi jìnnà sí mi.
19 Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn, àwọn aláìlẹ́bi fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,
20 wọ́n ń wí pé, ‘Dájúdájú, àwọn ọ̀tá wa ti parun, iná sì ti jó gbogbo ohun tí wọ́n fi sílẹ̀.’
21 “Nisinsinyii gba ti Ọlọrun, kí o sì wà ní alaafia; kí ó lè dára fún ọ.
22 Gba ìtọ́ni rẹ̀, kí o sì kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ lékàn.
23 Bí o bá yipada sí Olodumare, tí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀, tí o bá mú ìwà aiṣododo kúrò ní ibùgbé rẹ,
24 bí o bá ri wúrà mọ́ inú erùpẹ̀, tí o fi wúrà Ofiri sí ààrin àwọn òkúta ìsàlẹ̀ odò,
25 bí Olodumare bá sì jẹ́ wúrà rẹ, ati fadaka olówó iyebíye rẹ,
26 nígbà náà ni o óo láyọ̀ ninu Olodumare, o óo sì lè dúró níwájú Ọlọrun.
27 Nígbà náà, o óo gbadura sí i, yóo sì gbọ́, o óo sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 Ohunkohun tí o bá pinnu láti mú ṣe, yóo ṣeéṣe fún ọ, ìmọ́lẹ̀ yóo sì tàn sí ọ̀nà rẹ.
29 Nítorí Ọlọrun a máa rẹ onigbeeraga sílẹ̀, a sì máa gba onírẹ̀lẹ̀.
30 A máa gba àwọn aláìṣẹ̀, yóo sì gbà ọ́ là, nípa ìwà mímọ́ rẹ.”
1 Nígbà náà ni Jobu dáhùn pé,
2 “Lónìí, ìráhùn mi tún kún fún ẹ̀dùn, ọwọ́ Ọlọrun ń le lára mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mò ń kérora.
3 Áà! Ìbá jẹ́ pé mo mọ ibi tí mo ti lè rí i ni, ǹ bá lọ siwaju ìtẹ́ rẹ̀!
4 Ǹ bá ro ẹjọ́ mi níwájú rẹ̀, gbogbo ẹnu ni ǹ bá fi ṣàròyé.
5 Ǹ bá gbọ́ èsì tí yóo fún mi, ati ọ̀rọ̀ tí yóo sọ fún mi.
6 Ṣé yóo gbéjà kò mí pẹlu agbára ńlá rẹ̀? Rárá o, yóo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
7 Ibẹ̀ ni olódodo yóo ti lè sọ ti ẹnu rẹ̀, yóo sì dá mi sílẹ̀ títí lae.
8 “Wò ó! Mo lọ siwaju, kò sí níbẹ̀, mo pada sẹ́yìn, n kò gbúròó rẹ̀.
9 Mo wo apá ọ̀tún, n kò rí i, mo wo apá òsì, kò sí níbẹ̀.
10 Ṣugbọn ó mọ gbogbo ọ̀nà mi, ìgbà tí ó bá dán mi wò tán, n óo yege bíi wúrà.
11 Mò ń tẹ̀lé e lẹ́yìn, mo súnmọ́ ọn pẹ́kípẹ́kí, n kò tíì yipada kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
12 N kò tíì yapa kúrò ninu àṣẹ tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde, mò ń pa wọ́n mọ́ ninu ọkàn mi.
13 “Ṣugbọn Ọlọrun kìí yipada, kò sí ẹni tí ó lè yí i lọ́kàn pada. Ohun tí ó bá fẹ́ gan-an ni yóo ṣe.
14 Yóo ṣe ohun tí ó ti pinnu láti ṣe fún mi ní àṣeyọrí, ati ọpọlọpọ nǹkan bẹ́ẹ̀ yòókù tí ó tún ní lọ́kàn láti ṣe fún mi.
15 Ìdí nìyí tí ẹ̀rù fi bà mí níwájú rẹ̀, tí mo bá ro nǹkan wọnyi, jìnnìjìnnì rẹ̀ a bò mí.
16 Ọlọrun ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi, Olodumare ti dẹ́rùbà mí.
17 Nítorí pé òkùnkùn yí mi ká, òkùnkùn biribiri sì ṣú bò mí lójú.
1 “Kí ló dé tí Olodumare kò fi yan ọjọ́ ìdájọ́, kí àwọn tí wọ́n mọ̀ ọ́n sì rí ọjọ́ náà?
2 “Àwọn eniyan a máa hú òkúta ààlà kúrò, láti gba ilẹ̀ ẹlòmíràn kún tiwọn, wọn a máa fi ipá sọ agbo ẹran ẹlòmíràn di tiwọn.
3 Wọn a kó kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìníbaba lọ, wọn a gba akọ mààlúù opó gẹ́gẹ́ bí ohun ìdógò.
4 Wọn a ti àwọn aláìní kúrò lójú ọ̀nà, gbogbo àwọn talaka a sì lọ sápamọ́.
5 “Àwọn aláìní a máa ṣe làálàá káàkiri, bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ inú aṣálẹ̀, wọn a máa wá oúnjẹ fún àwọn ọmọ wọn ninu aṣálẹ̀.
6 Wọn a máa kó oúnjẹ jọ fún ẹran wọn ninu oko olóko wọn a sì máa he èso àjàrà ní oko ìkà.
7 Wọn a máa sùn ní ìhòòhò ní gbogbo òru, wọn kìí sìí rí aṣọ fi bora nígbà òtútù.
8 Òjò a pa wọ́n lórí òkè, wọn a máa rọ̀ mọ́ àpáta nítorí àìsí ààbò.
9 (Àwọn kan ń já àwọn ọmọ aláìníbaba gbà lẹ́nu ọmú, wọ́n sì ń gba ọmọ ọwọ́ lọ́wọ́ àwọn aláìní gẹ́gẹ́ bí ohun ìdógò.)
10 Àwọn aláìní ń rìn kiri ní ìhòòhò láìrí aṣọ wọ̀; ebi ń pa wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtí ọkà ni wọ́n rù.
11 Wọ́n ń fún òróró lára èso olifi tí ó wà ní oko ìkà, òùngbẹ sì ń gbẹ wọ́n, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọtí ni wọ́n ń pọn.
12 Àwọn tí wọn ń kú lọ ń kérora ní ìgboro, àwọn tí a pa lára ń ké fún ìrànlọ́wọ́, ṣugbọn Ọlọrun kò fetísí adura wọn.
13 “A rí àwọn tí wọ́n kọ ìmọ́lẹ̀, tí wọn kò mọ ọ̀nà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró ní ọ̀nà náà.
14 Bí ilẹ̀ bá ṣú, apànìyàn á dìde, kí ó lè pa talaka ati aláìní, a sì dàbí olè ní òru.
15 Alágbèrè pàápàá ń ṣọ́ kí ilẹ̀ ṣú, ó ń wí pé, ‘Kò sí ẹni tí yóo rí mi’; ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
16 Lóru, wọn á máa lọ fọ́ ilé kiri, ṣugbọn bí ilẹ̀ bá ti mọ́, wọn á ti ìlẹ̀kùn mọ́rí, wọn kì í rí ìmọ́lẹ̀.
17 Àárọ̀ ni òkùnkùn biribiri jẹ́ fún gbogbo wọn, ọ̀rẹ́ wọn ni òkùnkùn biribiri tí ó bani lẹ́rù.”
18 Sofari dáhùn pé, “O sọ wí pé, ‘Ìṣàn omi a máa gbá àwọn ẹni ibi lọ kíákíá; ìpín tiwọn a sì di ìfibú ninu ilẹ̀ náà, ẹnikẹ́ni kìí sì í lọ sinu ọgbà àjàrà wọn láti ṣiṣẹ́ mọ́.
19 Bí ọ̀gbẹlẹ̀ ati ooru ṣe máa ń mú kí omi yìnyín gbẹ bẹ́ẹ̀ ni ibojì ṣe ń gbé àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ mì.
20 Wọn á gbàgbé wọn láàrin ìlú, ẹnikẹ́ni kì í ranti orúkọ wọn mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi ṣe é wó lulẹ̀ bí ìtì igi.’
21 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ àgàn tí kò bímọ, wọn kò sì ṣe rere fún opó.
22 Sibẹsibẹ Ọlọrun fi ẹ̀mí gígùn fún alágbára nípa agbára rẹ̀; wọn á gbéra nígbà tí ayé bá sú wọn.
23 Ọlọrun ń dáàbò bò wọ́n, ó ń ràn wọ́n lọ́wọ́, ó sì ń pa wọ́n mọ́ ni ọ̀nà wọn.
24 A gbé wọn ga fún ìgbà díẹ̀, lẹ́yìn náà, a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn á rọ, wọn á sì rẹ̀ dànù bí ewé, a ké wọn kúrò bí orí ọkà bàbà.
25 Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, kí ẹnìkan já mi nírọ́, kí ó sì fi hàn pé ìsọkúsọ ni mò ń sọ.”
1 Bilidadi ará Ṣuha bá dáhùn pé,
2 “Ọlọrun ni ọba, òun ló sì tó bẹ̀rù, ó ń ṣe àkóso alaafia lọ́run.
3 Ta ló lè ka àwọn ọmọ ogun rẹ̀? Ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
4 Báwo wá ni eniyan ṣe lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun? Báwo ni ẹni tí obinrin bí ṣe lè jẹ́ ẹni mímọ́?
5 Wò ó, òṣùpá pàápàá kò mọ́lẹ̀ tó, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìràwọ̀ kò mọ́ tó lójú rẹ̀;
6 kí á má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ti eniyan tí ó dàbí ìdin, tabi ọmọ eniyan tí ó dàbí ekòló lásánlàsàn!”
1 Jobu bá dáhùn pé,
2 “Ìrànlọ́wọ́ wo ni ẹ ti ṣe fún àwọn tí wọn kò lágbára? Aláìlera wo ni ẹ ti gbàlà?
3 Ìmọ̀ràn wo ni ẹ ti fún àwọn aláìgbọ́n? Irú òye wo ni ẹ fihàn wọ́n?
4 Ta ló ń kọ yín ni ohun tí ẹ̀ ń sọ wọnyi? Irú ẹ̀mí wo sì ní ń gba ẹnu yín sọ̀rọ̀?
5 “Àwọn òkú wárìrì nísàlẹ̀. Omi ati àwọn olùgbé inú rẹ̀ pẹlu ń gbọ̀n rìrì.
6 Kedere ni isà òkú rí níwájú Ọlọrun, bẹ́ẹ̀ ni ìparun kò farasin.
7 Ó na ìhà àríwá sórí òfuurufú, ó sì so ayé rọ̀ sí òfuurufú.
8 Ó di omi papọ̀ ninu ìkùukùu rẹ̀ tí ó nípọn, sibẹ ìkùukùu kò fà ya.
9 Ó dí ojú òṣùpá, ó sì fi ìkùukùu bò ó.
10 Ó ṣe òbìrìkítí kan sórí omi, ó fi ṣe ààlà láàrin òkùnkùn ati ìmọ́lẹ̀.
11 Àwọn òpó ọ̀run mì tìtì, wọ́n sì wárìrì nítorí ìbáwí rẹ̀.
12 Nípa agbára rẹ̀, ó mú kí òkun parọ́rọ́, nípa ìmọ̀ rẹ̀, ó pa Rahabu.
13 Ó fi afẹ́fẹ́ ṣe ojú ọ̀run lọ́ṣọ̀ọ́; ọwọ́ ló fi pa ejò tí ń fò.
14 Ṣugbọn kékeré nìyí ninu agbára rẹ̀, díẹ̀ ni a tíì gbọ́ nípa iṣẹ́ rẹ̀! Nítorí náà ta ló lè mọ títóbi agbára rẹ̀?”
1 Jobu tún dáhùn pé,
2 “Mo fi Ọlọrun tí ó gba ẹ̀tọ́ mi búra, mo fi Olodumare tí ó mú kí ọkàn mi bàjẹ́ ṣẹ̀rí,
3 níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè, tí mo sì ń mí,
4 n kò ní fi ẹnu mi purọ́, ahọ́n mi kò sì ní sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
5 Kí á má rí i, n kò jẹ́ pè yín ní olóòótọ́; títí di ọjọ́ ikú mi ni n óo dúró lórí ọ̀rọ̀ mi, pé mo wà lórí àre.
6 Mo dúró lórí òdodo mi láìyẹsẹ̀, ọkàn mi kò ní dá mi lẹ́bi, títí n óo fi kú.
7 “Kí ó rí fún ọ̀tá mi gẹ́gẹ́ bí í ti í rí fún ẹni ibi, kí ó sì rí fún ẹni tí ó dojú kọ mí bí í ti í rí fún alaiṣododo.
8 Ìrètí wo ni ẹni tí kò mọ Ọlọrun ní nígbà tí Ọlọrun bá pa á run, tí Ọlọrun sì gba ẹ̀mí rẹ̀?
9 Ǹjẹ́ Ọlọrun yóo gbọ́ igbe rẹ̀, nígbà tí ìyọnu bá dé bá a?
10 Ǹjẹ́ yóo ní inú dídùn sí Olodumare? Ǹjẹ́ yóo máa ké pe Ọlọrun nígbà gbogbo?
11 “N óo kọ yín ní ìmọ̀ agbára Ọlọ́run; n kò sì ní fi ohun tíí ṣe ti Olodumare pamọ́.
12 Wò ó! Gbogbo yín ni ẹ ti fojú yín rí i, kí ló wá dé tí gbogbo yín fí ń sọ ìsọkúsọ?”
13 “Ìpín ẹni ibi láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun nìyí, òun ni ogún tí àwọn aninilára ń rí gbà lọ́dọ̀ Olodumare:
14 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá ń pọ̀ sí i, kí ogun baà lè pa wọ́n ni, oúnjẹ kò sì ní ká wọn lẹ́nu.
15 Àwọn ọmọ tí wọn bá gbẹ̀yìn rẹ̀, àjàkálẹ̀ àrùn ni yóo pa wọ́n, àwọn opó wọn kò sì ní ṣọ̀fọ̀ wọn.
16 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ń kó fadaka jọ bí erùpẹ̀, tí ó sì to aṣọ jọ bí amọ̀;
17 olódodo ni yóo wọ aṣọ tí ó bá kó jọ, àwọn aláìṣẹ̀ ni yóo pín fadaka rẹ̀.
18 Ilé tí ó kọ́ dàbí òwú aláǹtakùn, àní bí àgọ́ àwọn tí wọn ń ṣọ́nà.
19 A ti máa wọlé sùn pẹlu ọrọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn kò ní rí bẹ́ẹ̀ fún un mọ́. Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo ọrọ̀ rẹ̀ yóo ti fò lọ.
20 Ìwárìrì á bò ó mọ́lẹ̀ bí ìkún omi, ní alẹ́, ìjì líle á gbé e lọ.
21 Afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn á fẹ́ ẹ sókè, á sì gbé e lọ, á gbá a kúrò ní ipò rẹ̀.
22 Á dìgbò lù ú láìṣàánú rẹ̀, á sá lọ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
23 Ọlọrun á pàtẹ́wọ́ lé e lórí, á sì pòṣé sí i láti ibi tí ó wà.
1 “Dájúdájú, ibìkan wà tí wọ́n ti ń wa fadaka, ibìkan sì wà tí wọ́n ti ń yọ́ wúrà.
2 Inú ilẹ̀ ni a ti ń wa irin, a sì ń yọ́ idẹ lára òkúta.
3 Eniyan á sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀, a sì ṣe àwárí irin, ninu ọ̀gbun ati òkùnkùn biribiri.
4 Wọn á gbẹ́ kòtò ninu àfonífojì, níbi tí ó jìnnà sí ibi tí eniyan ń gbé, àwọn arìnrìnàjò á gbàgbé wọn, wọn á takété sí àwọn eniyan, wọn á sì máa rọ̀ dirodiro sọ́tùn-ún sósì.
5 Ní ti ilẹ̀, inú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde, ṣugbọn lábẹ́ rẹ̀, ó dàbí ẹnipé iná ń yí i po, ó gbóná janjan.
6 Safire ń bẹ ninu àwọn òkúta rẹ̀, wúrà sì ni erùpẹ̀ rẹ̀.
7 Ẹyẹ àṣá kò mọ ipa ọ̀nà ibẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ojú gúnnugún kò tó o.
8 Àwọn ẹranko onigbeeraga kò tíì tẹ ojú ọ̀nà náà, kinniun kò sì tíì gba ibẹ̀ kọjá rí.
9 “Eniyan á dá ọwọ́ rẹ̀ lé òkúta akọ, á gbẹ́ ẹ, á sì hú òkè ńlá tìdítìdí.
10 Á gbẹ́ ihò sinu àpáta, ojú rẹ̀ a sì tó àwọn ìṣúra iyebíye.
11 Á dí orísun àwọn odò, tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò fi lè sun, á sì wá àwọn ohun tí ó pamọ́ jáde.
12 Ṣugbọn níbo ni a ti lè rí ọgbọ́n? Níbo sì ni ìmọ̀ wà?
13 “Ẹnikẹ́ni kò mọ ọ̀nà ibi tí ó wà; bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ilẹ̀ alààyè.
14 Ibú sọ pé, ‘Kò sí ninu mi,’ òkun sì ní, ‘Kò sí lọ́dọ̀ mi.’
15 Wúrà iyebíye kò lè rà á, fadaka kò sì ṣe é díwọ̀n iye rẹ̀.
16 A kò lè fi wúrà Ofiri díwọ̀n iye rẹ̀, tabi òkúta onikisi tabi safire tí wọ́n jẹ́ òkúta olówó iyebíye.
17 Ọgbọ́n níye lórí ju wúrà ati dígí lọ, a kò lè fi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà dáradára ṣe dípò rẹ̀.
18 Kí á má tilẹ̀ sọ ti iyùn tabi Kristali, ọgbọ́n ní iye lórí ju òkúta Pali lọ.
19 A kò lè fi wé òkúta topasi láti ilẹ̀ Etiopia, tabi kí á fi ojúlówó wúrà rà á.
20 “Níbo ni ọgbọ́n ti ń wá; níbo sì ni ìmọ̀ wà?
21 Ó pamọ́ lójú gbogbo ẹ̀dá alààyè, ati lójú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Ìparun ati ikú jẹ́wọ́ pé, ‘Àhesọ ni ohun tí a gbọ́ nípa rẹ̀.’
23 “Ọlọrun nìkan ló mọ ọ̀nà rẹ̀, òun nìkan ló mọ ibùjókòó rẹ̀.
24 Nítorí pé ó ń wo gbogbo ayé, ó sì ń rí ohun gbogbo tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.
25 Nígbà tí ó fún afẹ́fẹ́ ní agbára, tí ó sì ṣe ìdíwọ̀n omi,
26 nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì lànà fún mànàmáná.
27 Lẹ́yìn náà ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde, ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, ó sì dán an wò.
28 Nígbà náà ni ó sọ fún eniyan pé, ‘Wò ó, ìbẹ̀rù OLUWA ni ọgbọ́n, kí á yẹra fún ibi sì ni ìmọ̀.’ ”
1 Jobu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ báyìí pé,
2 “Ìbá jẹ́ tún rí fún mi, bí ìgbà àtijọ́, nígbà tí Ọlọrun ń tọ́jú mi;
3 nígbà tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn sí mi lórí, tí mo kọjá ninu òkùnkùn pẹlu ìmọ́lẹ̀ rẹ̀;
4 kí ó tún rí fún mi bí ìgbà tí ara dẹ̀ mí, nígbà tí ìrẹ́pọ̀ wà láàrin Ọlọrun ati ìdílé mi;
5 tí Olodumare wà pẹlu mi, tí gbogbo àwọn ọmọ mi yí mi ká;
6 tí mò ń rí ọpọlọpọ wàrà lára àwọn ẹran ọ̀sìn mi, ati ọpọlọpọ òróró lára igi olifi tí ń dàgbà láàrin òkúta!
7 Nígbà tí mo lọ sí ẹnubodè ìlú, tí mo jókòó ní gbàgede,
8 tí àwọn ọdọmọkunrin bá rí mi, wọn á bìlà sẹ́gbẹ̀ẹ́ kan, àwọn àgbà á sì dìde dúró;
9 àwọn ìjòyè á dákẹ́ rọ́rọ́, wọn á fi ọwọ́ bo ẹnu wọn.
10 Àwọn olórí á panumọ́, ahọ́n wọn á lẹ̀ mọ́ wọn lẹ́nu.
11 Àwọn tí wọ́n gbọ́ nípa mi, ń pè mí ní ẹni ibukun, àwọn tí wọ́n rí mi ń kan sáárá sí mi.
12 Nítorí pé mò ń ran àwọn aláìní tí ń ké lọ́wọ́, ati àwọn aláìníbaba tí wọn kò ní olùrànlọ́wọ́.
13 Ìre àwọn tí ń kú lọ mọ́ mi, mo sì mú kí opó kọrin ayọ̀.
14 Mo fi òdodo bora bí aṣọ, ìdájọ́ òtítọ́ dàbí ẹ̀wù ati adé mi.
15 Mo jẹ́ ojú fún afọ́jú, ati ẹsẹ̀ fún arọ.
16 Mo jẹ́ baba fún talaka, mo gba ẹjọ́ àlejò rò.
17 Mo ṣẹ́ ẹni ibi lápá, mo gba ẹni tí ó mú sílẹ̀.
18 “Nígbà náà, mo rò pé, n óo gbòó, n óo tọ̀ọ́ láyé, ati pé inú ilé mi ni n óo sì kú sí.
19 Mo ta gbòǹgbò lọ síbi omi, ìrì sì ń sẹ̀ sí ẹ̀ka mi ní alaalẹ́.
20 Ọlá hàn lára mi, agbára mi sì ń di titun nígbà gbogbo.
21 Àwọn eniyan á dákẹ́ jẹ́ẹ́, wọn á farabalẹ̀ gbọ́ tèmi, wọ́n sì ń gba ìmọ̀ràn mi pẹlu.
22 Lẹ́yìn tí mo bá ti sọ̀rọ̀ tán, ẹnikẹ́ni kì í tún sọ̀rọ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ mi a máa wọ̀ wọ́n lára.
23 Wọ́n ń retí mi, bí ẹni retí òjò àkọ́rọ̀.
24 Mo rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn ń ṣiyèméjì, wọn kò sì lè kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá mi.
25 Mo jókòó bí ọba, mò ń tọ́ wọn sọ́nà, mo dàbí ọba láàrin àwọn ọmọ ogun rẹ̀, bí olùtùnú fún oníròbìnújẹ́.
1 “Ṣugbọn nisinsinyii àwọn tí wọ́n kéré sí mi ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà, àwọn tí baba wọn kò tó fi wé àwọn ajá tí ń ṣọ́ agbo ẹran mi.
2 Kí ni anfaani agbára wọn fún mi, àwọn tí wọn kò lókun ninu?
3 Ninu ìyà ati ebi, wọ́n ń jẹ gbòǹgbò igi gbígbẹ káàkiri lálẹ́ ninu aṣálẹ̀.
4 Ewé igi inú igbó ni wọ́n ń já jẹ, àní, àwọn igi ọwọ̀ tí kò ládùn kankan.
5 Wọ́n lé wọn jáde láàrin àwọn eniyan, wọ́n ń hó lé wọn lórí bí olè.
6 Wọ́n níláti máa gbé ojú àgbàrá, ninu ihò ilẹ̀, ati ihò àpáta.
7 Wọ́n ń dún bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ninu igbó, wọ́n ń kó ara wọn jọ sí abẹ́ igi ẹlẹ́gùn-ún.
8 Àwọn aláìlóye ọmọ, àwọn ọmọ eniyan lásán, àwọn tí a ti nà kúrò lórí ilẹ̀ náà.
9 “Nisinsinyii mo ti di orin lẹ́nu wọn, mo ti di àmúpòwe.
10 Mo di ẹni ìríra lọ́dọ̀ wọn, wọ́n ń rí mi sá, ara kò tì wọ́n láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Nítorí Ọlọrun ti sọ mí di aláìlera, ó sì ti rẹ̀ mí sílẹ̀, wọn dojú ìjà kọ mí ninu ibinu wọn.
12 Àwọn oníjàgídíjàgan dìde sí mi ní apá ọ̀tún mi, wọ́n lé mi kúrò, wọ́n sì la ọ̀nà ìparun sílẹ̀ fún mi.
13 Wọ́n dínà mọ́ mi, wọ́n dá kún wahala mi, kò sì sí ẹni tí ó lè dá wọn lẹ́kun.
14 Wọ́n jálù mí, bí ìgbà tí ọpọlọpọ ọmọ ogun bá gba ihò ara odi ìlú wọlé, wọ́n ya lù mí, wọ́n wó mi mọ́lẹ̀.
15 Ìbẹ̀rù-bojo dé bá mi, wọ́n ń lépa ọlá mi bí afẹ́fẹ́, ọlà mi sì parẹ́ bí ìkùukùu.
16 “Nisinsinyii, ẹ̀mí mi fò lọ ninu mi, ọjọ́ ìjìyà sì dé bá mi.
17 Ní òru, egungun ń ro mí, ìrora mi kò sì dínkù.
18 Ọlọrun fi ipá gba aṣọ mi, ó fún mi lọ́rùn bí ọrùn ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ mi.
19 Ó sọ mí sinu ẹrẹ̀, mo dàbí eruku ati eérú.
20 “Mo ké pè ọ́, Ọlọrun, O kò dáhùn, mo dìde dúró, mo gbadura, o kò kà mí sí.
21 O dojú ibinu kọ mí, o fi agbára rẹ bá mi jà.
22 O sọ mí sókè ninu afẹ́fẹ́, ò ń bì mí síhìn-ín sọ́hùn-ún láàrin ariwo ìjì líle.
23 Dájúdájú mo mọ̀ pé o óo gbé mi lọ sí ipò òkú, ilé tí o yàn fún gbogbo eniyan.
24 Bí ẹni tí a ti là mọ́lẹ̀, tí kò lè dìde, bá ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ninu ìnira, dájúdájú o kò tún ní gbé ìjà kò ó?
25 Ṣebí mo ti sọkún nítorí àwọn tí wọ́n wà ninu ìṣòro rí, tí mo sì káàánú àwọn aláìní.
26 Ṣugbọn nígbà tí mo bá ń retí ohun rere, ibi ní ń bá mi. Nígbà tí mo bá sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn ni mò ń rí.
27 Ọkàn mi dàrú, ara mi kò balẹ̀, ọjọ́ ìpọ́njú dé bá mi.
28 Mo fa ojú ro, mò ń káàkiri, mo dìde nàró láti bèèrè ìrànlọ́wọ́ láàrin àwùjọ.
29 Mò ń kígbe arò bí ajáko, mo di ẹgbẹ́ ẹyẹ ògòǹgò.
30 Àwọ̀ ara mi di dúdú, ó ń bó, egungun mi gbóná fún ooru.
31 Ọ̀fọ̀ dípò orin ayọ̀ fún mi, ẹkún sì dípò ohùn fèrè.
1 “Mo ti bá ojú mi dá majẹmu; n óo ṣe wá máa wo wundia?
2 Kí ni yóo jẹ́ ìpín mi lọ́dọ̀ Ọlọrun lókè? Kí ni ogún mi lọ́dọ̀ Olodumare?
3 Ṣebí jamba a máa bá àwọn alaiṣododo, àjálù a sì máa dé bá àwọn oníṣẹ́-ẹ̀ṣẹ̀.
4 Ṣebí Ọlọrun mọ ọ̀nà mi, ó sì mọ ìrìn mi.
5 Bí mo bá rìn ní ọ̀nà aiṣododo, tí mo sì yára láti sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn,
6 (kí Ọlọrun gbé mi ka orí ìwọ̀n tòótọ́, yóo sì rí i pé olóòótọ́ ni mí!)
7 Bí mo bá ti yí ẹsẹ̀ kúrò ní ọ̀nà tààrà, tí mò ń ṣe ojúkòkòrò, tí ọwọ́ mi kò sì mọ́,
8 jẹ́ kí ẹlòmíràn kórè oko mi, kí o sì fa ohun ọ̀gbìn mi tu.
9 “Bí ọkàn mi bá fà sí obinrin olobinrin, tabi kí n máa pẹ́ kọ̀rọ̀ lẹ́nu ọ̀nà aládùúgbò mi;
10 jẹ́ kí iyawo mi máa se oúnjẹ fún ẹlòmíràn, kí ẹlòmíràn sì máa bá a lòpọ̀.
11 Nítorí ó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó burú jù, ẹ̀ṣẹ̀ tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún.
12 Iná ajónirun ni, tí yóo run gbogbo ohun ìní mi kanlẹ̀.
13 “Bí mo bá kọ̀ láti fetí sí ẹjọ́ àwọn iranṣẹkunrin ati iranṣẹbinrin mi, nígbà tí wọ́n bá fẹ̀sùn kàn mí,
14 báwo ni n óo ṣe dúró níwájú Ọlọrun? Kí ni kí n wí nígbà tí ó bá bèèrè lọ́wọ́ mi?
15 Ṣebí ẹni tí ó dá mi ninu oyún, òun kan náà ló dá iranṣẹ mi? Òun ló mọ wá kí wọn tó bí wa.
16 “Bí mo bá fi ohunkohun pọ́n talaka lójú rí, tabi kí n fi opó sílẹ̀ ninu àìní,
17 tabi kí n dá oúnjẹ mi jẹ, láìfún ọmọ aláìníbaba jẹ
18 (láti ìgbà èwe rẹ̀ ni mo ti ń ṣe bíi baba fún un, tí mo sì ń tọ́jú rẹ̀ láti inú ìyá rẹ̀);
19 bí mo bá ti rí ẹni tí ó ń kú lọ, nítorí àìrí aṣọ bora, tabi talaka tí kò rí ẹ̀wù wọ̀,
20 kí ó sì súre fún mi, nítorí pé ara rẹ̀ móoru pẹlu aṣọ tí a fi irun aguntan mi hun,
21 bí mo bá fi ìyà jẹ aláìníbaba, nítorí pé mo mọ eniyan ní ilé ẹjọ́,
22 jẹ́ kí apá mi já kúrò léjìká mi, kí ó yọ ní oríkèé rẹ̀.
23 Nítorí ẹ̀rù ìpọ́njú láti ọ̀dọ̀ Ọlọrun ń bà mí, nítorí ògo rẹ̀, n kò lè dán irú rẹ̀ wò.
24 “Bí mo bá gbójú lé wúrà, tí mo sì fi ojúlówó wúrà ṣe igbẹkẹle mi,
25 bí mo bá ń yọ̀ nítorí pé mo ní ọrọ̀ pupọ, tabi nítorí pé ọwọ́ mi ti ba ọpọlọpọ ohun ìní.
26 Tí mo bá ti wo oòrùn nígbà tí ó ń ràn, tabi tí mo wo òṣùpá ninu ẹwà rẹ̀:
27 tí ọkàn mi fà sí wọn; tí mo sì tẹ́wọ́ adura sí wọn.
28 Èyí pẹlu yóo jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí adájọ́ gbọdọ̀ jẹ mí níyà fún; nítorí yóo jẹ́ aiṣootọ sí Ọlọrun ọ̀run.
29 “Bí mo bá yọ̀ nítorí ìparun ẹni tí ó kórìíra mi, tabi kí inú mi dùn nígbà tí ohun burúkú bá ṣẹlẹ̀ sí i.
30 (N kò fi ẹnu mi ṣẹ̀ kí n gbé e ṣépè pé kí ó lè kú);
31 bí àwọn tí wọn ń gbé inú àgọ́ mi kò bá wí pé, ‘Ta ló kù tí kò tíì yó?’
32 (Kò sí àlejò tí ń sun ìta gbangba, nítorí ìlẹ̀kùn ilé mi ṣí sílẹ̀ fún àwọn arìnrìnàjò);
33 bí mo bá fi ẹ̀ṣẹ̀ mi pamọ́ fún eniyan, tí mo sì dé àìdára mi mọ́ra,
34 nítorí pé mò ń bẹ̀rù ọpọlọpọ eniyan, ẹ̀gàn ìdílé sì ń dẹ́rùbà mí, tóbẹ́ẹ̀ tí mo fi dákẹ́, tí n kò sì jáde síta.
35 Ha! Ǹ bá rí ẹni gbọ́ tèmi! (Mo ti tọwọ́ bọ̀wé, kí Olodumare dá mi lóhùn!) Ǹ bá lè ní àkọsílẹ̀ ẹ̀sùn tí àwọn ọ̀tá fi kàn mí!
36 Dájúdájú, ǹ bá gbé e lé èjìká mi, ǹ bá fi dé orí bí adé;
37 ǹ bá sọ gbogbo ìgbésẹ̀ mi fún Ọlọrun, ǹ bá bá a sọ̀rọ̀ bí ìjòyè.
38 “Bí ilẹ̀ mi bá kígbe ẹ̀san lé mi lórí, tí àwọn poro oko mi sì ń sọkún;
39 tí mo bá jẹ ninu ìkórè ilẹ̀ náà láìsanwó rẹ̀, tabi tí mo sì ṣe ikú pa ẹni tí ó ni ín,
40 kí ẹ̀gún hù lórí ilẹ̀ náà dípò ọkà, kí koríko hù dípò ọkà baali.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí síhìn-ín.
1 Àwọn ọkunrin mẹtẹẹta náà kò dá Jobu lóhùn mọ́, nítorí pé ó jẹ́ olódodo lójú ara rẹ̀.
2 Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, ní ìdílé Ramu bá bínú sí Jobu, nítorí pé ó dá ara rẹ̀ láre dípò Ọlọrun.
3 Ó bínú sí àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹtẹẹta pẹlu, nítorí pé wọn kò mọ èsì tí wọ́n lè fún Jobu mọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n dá a lẹ́bi.
4 Elihu ti fẹ́ bá Jobu sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn ó dákẹ́, nítorí àwọn àgbà tí wọ́n jù ú lọ ni wọ́n ń sọ̀rọ̀.
5 Ṣugbọn nígbà tí Elihu rí i pé àwọn mẹtẹẹta kò lè fún Jobu lésì mọ́, inú bí i.
6 Ó ní, “Àgbàlagbà ni yín, ọmọde sì ni mí, nítorí náà ni ojú fi ń tì mí, tí ẹ̀rù sì ń bà mí láti sọ èrò ọkàn mi.
7 Mo ní kí ẹ̀yin àgbà sọ̀rọ̀, kí ọ̀rọ̀ yín sì fa ọgbọ́n yọ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí yín.
8 Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu eniyan, tíí ṣe èémí Olodumare, ni ó ń fún eniyan ní ìmọ̀.
9 Kì í ṣe àwọn àgbà nìkan ni wọ́n gbọ́n, tabi pé arúgbó nìkan ni ó mọ òye ohun tó tọ́, tó yẹ.
10 Nítorí náà, ‘Ẹ fetí sílẹ̀, kí èmi náà lè sọ èrò ọkàn mi.’
11 “Mo farabalẹ̀ nígbà tí ẹ̀yin ń sọ̀rọ̀, mo fetí sí ọ̀rọ̀ ọgbọ́n yín, nígbà tí ẹ̀ ń ronú ohun tí ẹ fẹ́ sọ,
12 Mo farabalẹ̀ fun yín, ṣugbọn kò sí ẹnikẹ́ni ninu yín tí ó lè ko Jobu lójú, kí ó sì fi àṣìṣe rẹ̀ hàn án, tabi kí ó fún un lésì àwọn àwíjàre rẹ̀.
13 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má baà wí pé, ‘A ti di ọlọ́gbọ́n, Ọlọrun ló lè ṣe ìdájọ́ rẹ̀, kì í ṣe eniyan.’
14 Èmi kọ́ ni Jobu ń bá wí, ẹ̀yin ni, n kò sì ní dá a lóhùn bí ẹ ṣe dá a lóhùn.
15 “Ọkàn wọn dàrú, wọn kò sì lè fèsì mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ohun kan láti sọ.
16 Ṣé kí n dúró, nítorí pé wọ́n dúró láìfèsì?
17 Èmi náà óo fèsì lé e, n óo sì sọ èrò ọkàn tèmi.
18 Mo ní ọ̀rọ̀ pupọ láti sọ, Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu mi ló ń kó mi ní ìjánu.
19 Ọ̀rọ̀ kún inú mi bí ọtí inú ìgò, ó fẹ́ ru síta bí ọtí inú ìgò aláwọ.
20 Mo níláti sọ̀rọ̀ kí ara lè rọ̀ mí, mo gbọdọ̀ la ẹnu mi kí n sì dáhùn.
21 N kò ní ṣe ojuṣaaju ẹnikẹ́ni, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì ní gbèjà eniyan.
22 Nítorí n kò mọ bí wọ́n ṣe ń pọ́n eniyan, kí Ẹlẹ́dàá mi má baà pa mí run ní kíá.
1 “Jobu, tẹ́tí sílẹ̀ nisinsinyii kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
2 Wò ó! Mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ sì pọ̀ tí mo fẹ́ sọ.
3 Òtítọ́ inú ni mo fi fẹ́ sọ̀rọ̀, ohun tí mo mọ̀ pé òdodo ni ni mo sì fẹ́ sọ.
4 Ẹ̀mí Ọlọrun ni ó dá mi, èémí Olodumare ni ó sì fún mi ní ìyè.
5 “Bí o bá lè dá mi lóhùn, dáhùn. Ro ohun tí o fẹ́ sọ dáradára, kí o sì múra láti wí àwíjàre.
6 Wò ó, bákan náà ni èmi pẹlu rẹ rí lójú Ọlọrun, amọ̀ ni a fi mọ èmi náà.
7 Má jẹ́ kí ẹ̀rù mi bà ọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò ní le kankan mọ́ ọ.
8 “Lóòótọ́, o ti sọ̀rọ̀ ní etígbọ̀ọ́ mi, mo sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ.
9 O ní o mọ́, o kò ní ẹ̀ṣẹ̀, ara rẹ mọ́ o kò sì ṣe àìdára kankan.
10 Sibẹ Ọlọrun wá ẹ̀sùn sí ọ lẹ́sẹ̀, ó sọ ọ́ di ọ̀tá rẹ̀,
11 ó kan ààbà mọ́ ọ lẹ́sẹ̀, ó sì ń ṣọ́ ìrìn rẹ.
12 “Jobu, n óo dá ọ lóhùn, nítorí pé bí o ti wí yìí, bẹ́ẹ̀ kọ́ lọ̀rọ̀ rí. Ọlọrun ju eniyan lọ.
13 Kí ló dé tí ò ń fi ẹ̀sùn kàn án pé kò ní fèsì kankan sí ọ̀rọ̀ rẹ?
14 Nítorí Ọlọrun sọ̀rọ̀ bákan, ó tún tún un sọ bámìíràn, ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yé.
15 Ninu àlá, lójú ìran ní ààrin òru, nígbà tí eniyan bá sun oorun àsùnwọra, lórí ibùsùn wọn,
16 Ọlọrun a máa ṣí wọn létí, a máa kìlọ̀ fún wọn, a sì máa dẹ́rùbà wọ́n,
17 kí ó lè dá wọn lẹ́kun ìṣe wọn, kí ó lè gba ìgbéraga lọ́wọ́ wọn;
18 kí ó lè yọ ọkàn eniyan kúrò ninu ọ̀fìn ìparun, kí ó má baà kú ikú idà.
19 “OLUWA a máa fi ìrora jẹ eniyan níyà lórí ibùsùn rẹ̀; a sì máa kó ìnira bá egungun rẹ̀.
20 Tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnu rẹ̀ yóo kọ oúnjẹ, oúnjẹ àdídùn óo sì rùn sí i.
21 Eniyan á rù hangangan, wọn a sì fẹ́rẹ̀ lè máa ka egungun rẹ̀.
22 Ọkàn rẹ̀ á súnmọ́ ibojì, ẹ̀mí rẹ̀ a sì súnmọ́ àwọn iranṣẹ ikú.
23 Bí angẹli kan bá wà pẹlu rẹ̀, tí ó wà fún un bí onídùúró, àní, ọ̀kan láàrin ẹgbẹrun, tí yóo sọ ohun tí ó tọ́ fún un,
24 tí yóo ṣàánú rẹ̀, tí yóo sì wí pé, ‘Ẹ gbà á sílẹ̀, ẹ má jẹ́ kí ó lọ sinu ibojì, mo ti rí ìràpadà kan dípò rẹ̀.’
25 Jẹ́ kí àwọ̀ rẹ̀ jọ̀lọ̀ bí ara ọmọde, kí agbára rẹ̀ sì pada dàbí ti ìgbà ọ̀dọ́;
26 nígbà náà eniyan óo gbadura sí Ọlọrun, Ọlọrun óo sì gbọ́ adura rẹ̀. Eniyan óo wá fi ayọ̀ wá siwaju Ọlọrun, yóo sì ròyìn ìgbàlà Ọlọrun fún gbogbo aráyé
27 Yóo wá sọ gbangba níwájú àwọn eniyan pé, ‘Mo ti ṣẹ̀, mo sì ti yí ẹ̀tọ́ po, ṣugbọn Ọlọrun kò jẹ mí níyà ẹ̀ṣẹ̀ mi.
28 Ó ti ra ọkàn mi pada kúrò lọ́wọ́ isà òkú, mo sì wà láàyè.’
29 “Wò ó, Ọlọrun a máa ṣe nǹkan wọnyi léraléra fún eniyan, lẹẹmeji tabi lẹẹmẹta,
30 láti lè gba ọkàn rẹ̀ là lọ́wọ́ ikú, kí ó lè wà láàyè.
31 “Gbọ́, ìwọ Jobu, farabalẹ̀, dákẹ́ kí o lè gbọ́ ohun tí n óo sọ.
32 Bí o bá ní ohunkohun láti sọ, dá mi lóhùn; sọ̀rọ̀, nítorí pé mo fẹ́ dá ọ láre ni.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, tẹ́tí sí mi; farabalẹ̀, n óo sì kọ́ ọ lọ́gbọ́n.”
1 Elihu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ bọ̀, ó ní,
2 “Ẹ gbọ́rọ̀ mi, ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n, ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ẹ ní ìmọ̀,
3 nítorí bí ahọ́n ti í máa ń tọ́ oúnjẹ wò, bẹ́ẹ̀ ni etí náà lè máa tọ́ ọ̀rọ̀ wò
4 Ẹ jẹ́ kí á yan ohun tí ó tọ́, kí á jọ jíròrò ohun tí ó dára láàrin ara wa.
5 Jobu sọ pé òun kò jẹ̀bi, ó ní Ọlọrun ni ó kọ̀ tí kò dá òun láre.
6 Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun jàre, Ọlọrun ka òun kún òpùrọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò dẹ́ṣẹ̀, ọgbẹ́ òun kò ṣe é wòsàn.
7 “Ta ló dàbí Jobu, tí ń kẹ́gàn Ọlọrun nígbà gbogbo,
8 tí ó ń bá àwọn aṣebi kẹ́gbẹ́, tí ó sì ń bá àwọn eniyan burúkú rìn?
9 Nítorí ó ń sọ pé, ‘Kò sí èrè kankan, ninu ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun.’
10 “Nítorí náà ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin olóye, Ọlọrun kì í ṣe ibi, Olodumare kì í ṣe ohun tí kò tọ́.
11 Nítorí a máa san ẹ̀san fún eniyan gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ ati gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ̀.
12 Nítòótọ́, Ọlọrun kì í ṣe ibi, bẹ́ẹ̀ ni Olodumare kì í dájọ́ èké.
13 Ta ló fi í ṣe alákòóso ayé, ta ló sì fi jẹ olórí gbogbo ayé?
14 Bí Ọlọrun bá gba ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, tí ó sì gba èémí rẹ̀ pada sọ́dọ̀,
15 gbogbo eniyan ni yóo ṣègbé, tí wọn yóo sì pada di erùpẹ̀.
16 “Bí ẹ bá ní òye, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ.
17 Ǹjẹ́ ẹni tí ó kórìíra ìdájọ́ ẹ̀tọ́ lè jẹ́ olórí? Àbí ẹ lè dá olódodo ati alágbára lẹ́bi?
18 Ẹni tí ó tó pe ọba ní eniyan lásán, tí ó tó pe ìjòyè ní ẹni ibi;
19 ẹni tí kì í ṣe ojuṣaaju fún àwọn ìjòyè, tí kì í sì í ka ọlọ́rọ̀ sí ju talaka lọ, nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn.
20 Wọn á kú ikú òjijì, ní ọ̀gànjọ́ òru; á mi gbogbo eniyan jìgìjìgì, wọn a sì kú. Ikú á mú àwọn alágbára lọ láì jẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn wọ́n.
21 Nítorí pé ojú rẹ̀ tó gbogbo ọ̀nà tí eniyan ń tọ̀, ó sì rí gbogbo ìrìn ẹsẹ̀ wọn.
22 Kò sí ibi òkùnkùn biribiri kankan, tí àwọn eniyan burúkú lè fi ara pamọ́ sí.
23 Nítorí Ọlọrun kò nílò láti yan àkókò kan fún ẹnikẹ́ni, láti wá siwaju rẹ̀ fún ìdájọ́.
24 Á pa àwọn alágbára run láìṣe ìwádìí wọn, á sì fi àwọn ẹlòmíràn dípò wọn.
25 Nítorí pé ó mọ iṣẹ́ ọwọ́ wọn, á bì wọ́n ṣubú lóru, wọn á sì parun.
26 Á máa jẹ wọ́n níyà ní gbangba, nítorí ìwà ibi wọn.
27 Nítorí pé wọ́n kọ̀ láti tẹ̀lé e, wọn kò náání ọ̀nà rẹ̀ kankan,
28 wọ́n ń jẹ́ kí àwọn talaka máa kígbe sí Ọlọrun, a sì máa gbọ́ igbe àwọn tí a ni lára.
29 “Bí Ọlọrun bá dákẹ́, ta ló lè bá a wí? Nígbà tí ó bá fi ojú pamọ́, orílẹ̀-èdè tabi eniyan wo ló lè rí i?
30 Kí ẹni ibi má baà lè ṣe àkóso, kí ó má baà kó àwọn eniyan sinu ìgbèkùn.
31 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tíì sọ fún Ọlọrun pé, ‘Mo ti jìyà rí, n kò sì ní gbẹ̀ṣẹ̀ mọ́.
32 Kọ́ mi ní ohun tí n kò rí, bí mo bá ti ṣẹ̀ rí, n kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́?’
33 Ṣé yóo san ẹ̀san fún ọ lọ́nà tí ó tẹ́ ọ lọ́rùn, nítorí pé o kọ̀ ọ́? Nítorí ìwọ ni o gbọdọ̀ yan ohun tí ó bá wù ọ́, kì í ṣe èmi, nítorí náà, sọ èrò ọkàn rẹ fún wa.
34 Àwọn tí wọ́n lóye yóo sọ fún mi, àwọn ọlọ́gbọ́n tí wọn ń gbọ́ mi yóo sọ pẹlu pé,
35 ‘Jobu ń sọ̀rọ̀ láìní ìmọ̀, ó ń sọ̀rọ̀ láìní òye tí ó jinlẹ̀.’
36 À bá lè gbé ọ̀rọ̀ Jobu yẹ̀wò títí dé òpin, nítorí pé ó ń sọ̀rọ̀ bí eniyan burúkú.
37 Ó fi ọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá; ó ń pàtẹ́wọ́ ẹlẹ́yà láàrin wa, ó sì ń kẹ́gàn Ọlọrun.”
1 Elihu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ bọ̀, ó ní,
2 “Jobu, ṣé o rò pé ó tọ̀nà, kí o máa sọ pé, ‘Ọ̀nà mi tọ́ níwájú Ọlọrun?’
3 Kí o tún máa bèèrè pé, ‘Anfaani wo ni mo ní? Tabi kí ni mo fi sàn ju ẹni tí ó dẹ́ṣẹ̀ lọ?’
4 N óo dá ìwọ ati àwọn ọ̀rẹ́ rẹ lóhùn.
5 Gbójú sókè kí o wo ojú ọ̀run, ati àwọn ìkùukùu tí ó wà lókè.
6 Bí o bá dẹ́ṣẹ̀, kò ṣe Ọlọrun ní àìrójú, bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bá pọ̀, kò jámọ́ nǹkankan fún un.
7 Bí o bá jẹ́ olódodo, kí ni ó dà fún Ọlọrun, tabi kí ni ó ń rí gbà lọ́wọ́ rẹ?
8 Àwọn eniyan burúkú bíì rẹ, ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ lè pa lára, àwọn ọmọ eniyan ni òdodo rẹ sì lè jẹ́ anfaani fún.
9 “Àwọn eniyan ń kígbe nítorí ọpọlọpọ ìnira, wọ́n ń bẹ̀bẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́, nítorí àwọn alágbára ń tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó bèèrè pé, ‘Níbo ni Ọlọrun Ẹlẹ́dàá mi wà, tíí fún ni ní orin ayọ̀ lóru,
11 ẹni tí ó ń kọ́ wa lẹ́kọ̀ọ́ ju àwọn ẹranko lọ, Ó sì fún wa ní ọgbọ́n ju àwọn ẹyẹ lọ?’
12 Wọ́n kígbe níbẹ̀ ṣugbọn kò dá wọn lóhùn, nítorí ìgbéraga àwọn eniyan burúkú.
13 Dájúdájú Ọlọrun kì í gbọ́ igbe asán, Olodumare kò tilẹ̀ náání rẹ̀.
14 Kí á má tilẹ̀ sọ ti ìwọ Jobu, tí o sọ pé o kò rí i, ati pé ẹjọ́ rẹ wà níwájú rẹ̀, o sì ń dúró dè é!
15 Ṣugbọn nisinsinyii, nítorí pé inú kì í bí i kí ó jẹ eniyan níyà, bẹ́ẹ̀ ni kò ka ẹ̀ṣẹ̀ kún lọ títí.
16 Jobu kàn ń la ẹnu, ó sì ń sọ̀rọ̀ lásán ni. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ pọ̀, ṣugbọn kò mú ọgbọ́n lọ́wọ́.”
1 Elihu tún tẹ̀síwájú ninu ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó ní,
2 “Ní sùúrù fún mi díẹ̀, n óo ṣe àlàyé fún ọ, nítorí mo ní ohun kan tí mo fẹ́ gbẹnusọ fún Ọlọrun.
3 N óo gba ìmọ̀ mi láti ọ̀nà jíjìn, n óo sì fi júbà Ẹlẹ́dàá mi, tí ó ní ìmọ̀ òdodo.
4 Nítorí òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ mi; ẹni tí ìmọ̀ rẹ̀ péye ni èmi tí mò ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí.
5 “Ọlọrun lágbára, kì í kẹ́gàn ẹnikẹ́ni, agbára ati òye rẹ̀ pọ̀ gan-an.
6 Kì í jẹ́ kí eniyan burúkú ó wà láàyè, ṣugbọn a máa fún ẹni tí ìyà ń jẹ ní ẹ̀tọ́ rẹ̀.
7 Kìí mú ojú kúrò lára àwọn olódodo, ṣugbọn a máa gbé wọn sórí ìtẹ́ pẹlu àwọn ọba, á gbé wọn ga, á sì fi ìdí wọn múlẹ̀ títí lae.
8 Ṣugbọn bí a bá fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè wọ́n, tí ayé wọn kún fún ìpọ́njú,
9 a máa fi àṣìṣe wọn hàn wọ́n, ati ẹ̀ṣẹ̀ ìgbéraga wọn.
10 Ó fún wọn ní etígbọ̀ọ́, ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n yipada kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀.
11 Bí wọ́n bá gbọ́ràn, tí wọ́n sì sìn ín, wọn yóo lo ọjọ́ ayé wọn pẹlu ìdẹ̀rùn, wọn yóo ṣe ọ̀pọ̀ ọdún ninu ìgbádùn.
12 Ṣugbọn bí wọn kò bá gbọ́ràn, a óo fi idà pa wọ́n, wọn yóo sì kú láìní ìmọ̀.
13 “Àwọn tí kò mọ Ọlọrun fẹ́ràn ibinu, wọn kì í kígbe fún ìrànlọ́wọ́, nígbà tí ó bá fi wọ́n sinu ìdè.
14 Wọn á kú ikú ìtìjú, nígbà tí wọ́n wà ní èwe.
15 A máa lo ìpọ́njú àwọn tí à ń pọ́n lójú láti gbà wọ́n là, a sì máa lo ìdààmú wọn láti ṣí wọn létí.
16 A máa yọ ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú, bọ́ sinu ìdẹ̀ra níbi tí kò sí wahala, oúnjẹ tí a gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀ a sì jẹ́ kìkì àdídùn.
17 “Ṣugbọn, ìdájọ́ eniyan burúkú dé bá ọ, ọwọ́ ìdájọ́ ati òdodo sì ti tẹ̀ ọ́.
18 Ṣọ́ra kí ibinu má baà sọ ọ́ di ẹlẹ́yà, kí títóbi àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì mú ọ ṣìnà.
19 Igbe ati agbára rẹ kò lè gbà ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú.
20 Má máa dúró, kí o máa retí ọjọ́ alẹ́, nígbà tí à ń pa àwọn eniyan run.
21 Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀, tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.
22 “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀; ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?
23 Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un, tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’
24 Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.
25 Gbogbo eniyan ti rí i; àwọn tí wọ́n wà ní òkèèrè ń wò ó.
26 Wò ó, Ọlọrun tóbi lọ́ba, ju ìmọ̀ wa lọ, kò sí ẹni tí ó lè mọ ọjọ́ orí rẹ̀.
27 “Ó fa ìkán omi sókè láti inú ilẹ̀, ó sọ ìkùukùu di òjò,
28 ó sì rọ òjò sílẹ̀ láti ojú ọ̀run sórí ọmọ eniyan lọpọlọpọ.
29 Ta ló mọ bí ó ti tẹ́ ìkùukùu? Tabi bí ó ṣe ń sán ààrá láti inú àgọ́ rẹ̀?
30 Ó fi mànàmáná yí ara rẹ̀ ká, ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
31 Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe ń ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè; ó sì ń fún wọn ní oúnjẹ lọpọlọpọ.
32 Ìkáwọ́ rẹ̀ ni mànàmáná wà, ó sì ń rán ààrá láti sán lu ohun tí ó bá fẹ́.
33 Ìró ààrá ń kéde bíbọ̀ rẹ̀, àwọn ẹran ọ̀sìn sì mọ̀ pé ó súnmọ́ tòsí.
1 “Nígbà tí mo gbọ́, ọkàn mi wárìrì, ó sì fò sókè ní ipò rẹ̀.
2 Gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ń dún bí ààrá, ati ariwo tí ń ti ẹnu rẹ̀ jáde.
3 Ó rán mànàmáná rẹ̀ sí wọn jákèjádò ojú ọ̀run, títí dé òpin ilẹ̀ ayé.
4 Lẹ́yìn náà, a gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, ó sọ̀rọ̀ ninu ọlá ńlá rẹ̀, bí ìgbà tí ààrá bá sán, sibẹsibẹ kò dá mànàmáná dúró bí àwọn eniyan ti ń gbóhùn rẹ̀.
5 Ohùn Ọlọrun dún bí ààrá tìyanu-tìyanu, a kò lè rí ìdí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
6 Ó pàṣẹ pé kí yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni òjò wẹliwẹli, ati ọ̀wààrà òjò.
7 Ó ká gbogbo eniyan lọ́wọ́ iṣẹ́ kò, kí wọ́n lè mọ iṣẹ́ rẹ̀.
8 Àwọn ẹranko wọ ihò wọn lọ, wọ́n dákẹ́ sibẹ, wọ́n sá pamọ́.
9 Ìjì líle fẹ́ jáde láti inú yàrá rẹ̀, òtútù sì mú wá láti inú afẹ́fẹ́ tí ń fẹ́.
10 Yìnyín ti inú èémí Ọlọrun wá, gbogbo omi inú odò sì dì.
11 Ó fi omi kún inú ìkùukùu, ìkùukùu sì fọ́n mànàmáná rẹ̀ ká.
12 Wọ́n ń yípo lábẹ́ ìtọ́ni rẹ̀, láti mú gbogbo àṣẹ tí ó pa ṣẹ, lórí ilẹ̀ alààyè.
13 Ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi ṣẹlẹ̀, bóyá fún àtúnṣe ni, tabi nítorí ilẹ̀ rẹ̀, tabi láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
14 “Fetí sílẹ̀, ìwọ Jobu, dúró kí o sì ronú nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu Ọlọrun.
15 Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọrun ṣe pàṣẹ, tí ó sì mú kí mànàmáná awọsanma tàn?
16 Ǹjẹ́ o mọ̀ bí ó ṣe so awọsanma rọ̀, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ ni;
17 ìwọ tí ooru mú nígbà tí ayé dákẹ́ rọ́rọ́ nítorí pé afẹ́fẹ́ ìhà gúsù kò fẹ́?
18 Ṣé o lè tẹ́ ojú ọ̀run bí ó ti tẹ́ ẹ, kí ó le, kí ó sì dàbí dígí tí ń dán?
19 Kọ́ wa ní ohun tí a lè bá Ọlọrun sọ, a kò lè kó àròyé wa jọ siwaju rẹ̀, nítorí àìmọ̀kan wa.
20 Ṣé kí n sọ fún Ọlọrun pé n ó bá a sọ̀rọ̀ ni? Ta ni yóo fẹ́ kí á gbé òun mì?
21 “Ẹnikẹ́ni kò lè wo ìmọ́lẹ̀ ojú ọ̀run nígbà tí ó bá ń tàn ní awọsanma, nígbà tí afẹ́fẹ́ bá fẹ́ tí ó sì gbá wọn lọ.
22 Láti ìhà àríwá ni Ọlọrun ti yọ, ó fi ọlá ńlá, tí ó bani lẹ́rù, bora bí aṣọ.
23 Àwámárìídìí ni Olodumare– agbára ati ìdájọ́ òtítọ́ rẹ̀ pọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì í kọ òdodo sílẹ̀.
24 Nítorí náà, gbogbo eniyan bẹ̀rù rẹ̀, kò sì náání àwọn tí wọ́n gbọ́n lójú ara wọn.”
1 Nígbà náà ni OLUWA dá Jobu lóhùn láti inú ìjì líle.
2 Ó bi í pé, “Ta ni ẹni tí ń bu ẹnu àtẹ́ lu ìmọ̀ràn, tí ń sọ̀rọ̀ tí kò ní ìmọ̀?
3 Nisinsinyii, múra gírí bí ọkunrin, mo ní ìbéèrè kan láti bí ọ, o óo sì dá mi lóhùn.
4 Níbo lo wà, nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Bí o bá mọ ìgbà náà, sọ fún mi.
5 Ta ló ṣe ìdíwọ̀n rẹ̀– ṣebí o mọ̀ ọ́n, dá mi lóhùn! Àbí ta ló ta okùn ìwọ̀n sórí rẹ̀?
6 Orí kí ni a gbé ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé, àbí ta ló fi òkúta igun rẹ̀ sọlẹ̀;
7 tí àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ ń jùmọ̀ kọrin, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọrun sì búsáyọ̀?
8 Ta ló tìlẹ̀kùn mọ́ òkun, nígbà tí ó ń ru jáde,
9 tí mo fi awọsanma ṣe ẹ̀wù rẹ̀, tí òkùnkùn biribiri sì jẹ́ ọ̀já ìgbànú rẹ̀,
10 tí mo sì pa ààlà fún un, tí mo sé ìlẹ̀kùn mọ́ ọn,
11 tí mo wí pé, ‘Dúró níhìn-ín, o kò gbọdọ̀ kọjá ibẹ̀, ibí ni ìgbì líle rẹ ti gbọdọ̀ dáwọ́ dúró?’
12 Jobu, láti ọjọ́ tí o ti dé ayé, ǹjẹ́ o ti pàṣẹ pé kí ilẹ̀ mọ́ rí, tabi pé kí àfẹ̀mọ́jú mọ́ àkókò rẹ̀,
13 kí ìmọ́lẹ̀ lè tàn sí gbogbo ayé, kí ó sì lè gbọn àwọn ẹni ibi dànù, kúrò ní ibi ìsápamọ́sí wọn?
14 A ti yí ayé pada bí amọ̀ tí a fi òǹtẹ̀ tẹ̀, ati bí aṣọ tí a pa láró.
15 A mú ìmọ́lẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹni ibi, a sì ká wọn lápá kò.
16 “Ṣé o ti wọ orísun òkun lọ rí, tabi o ti rìn nísàlẹ̀ ibú rí?
17 Ṣé a ti fi ìlẹ̀kùn ikú hàn ọ́ rí, tabi o ti rí ìlẹ̀kùn òkùnkùn biribiri rí?
18 Ṣé o mọ̀ bí ayé ti tóbi tó? Dá mi lóhùn, bí o bá mọ àwọn nǹkan wọnyi.
19 “Níbo ni ọ̀nà ilé ìmọ́lẹ̀, ibo sì ni ibùgbé òkùnkùn,
20 tí o óo fi lè mú un lọ sí ààyè rẹ̀, tí o fi lè mọ ọ̀nà tí ó lọ sí ilé rẹ̀?
21 Dájúdájú o mọ̀, nítorí pé wọ́n ti bí ọ nígbà náà, o sá ti dàgbà!
22 “Ṣé o ti wọ àwọn ilé ìkẹ́rùsí, tí mò ń kó yìnyín pamọ́ sí rí, tabi ibi tí mò ń kó òjò dídì sí,
23 àní, àwọn tí mo ti pamọ́ de àkókò ìyọnu, fún ọjọ́ ogun ati ọjọ́ ìjà?
24 Ṣé o mọ ibi tí ìmọ́lẹ̀ ti ń tàn wá, tabi ibi tí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ti ń fẹ́ wá sórí ayé?
25 “Ta ló lànà fún ọ̀wààrà òjò, ati fún ààrá,
26 láti rọ òjò sí orí ilẹ̀ níbi tí kò sí eniyan, ati ní aṣálẹ̀, níbi tí kò sí ẹnikẹ́ni?
27 Láti tẹ́ aṣálẹ̀ lọ́rùn, ati láti mú kí ilẹ̀ hu koríko?
28 Ṣé òjò ní baba; àbí, baba wo ló sì bí ìrì?
29 Ìyá wo ló bí yìnyín, inú ta ni òjò dídì sì ti jáde?
30 Ó sọ omi odò di líle bí òkúta, ojú ibú sì dì bíi yìnyín.
31 “Ṣé o lè fokùn so ìràwọ̀ Pileiadesi, tabi kí o tú okùn ìràwọ̀ Orioni?
32 Ṣé o lè darí àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀, ní àkókò wọn, tabi kí o ṣe atọ́nà ìràwọ̀ Beari ati àwọn ọmọ rẹ̀?
33 Ṣé o mọ àwọn òfin tí ó de ojú ọ̀run? Tabi o lè fìdí wọn múlẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé?
34 “Ǹjẹ́ o lè pàṣẹ fún ìkùukùu pé, kí ó rọ òjò lé ọ lórí?
35 Ṣé o lè pe mànàmáná pé kí ó wá kí o rán an níṣẹ́ kí ó wá bá ọ kí ó wí pé, ‘Èmi nìyí?’
36 Ta ló fi ọgbọ́n sinu ìkùukùu ati ìmọ̀ sinu ìrì?
37 Ta ló lè fi ọgbọ́n ká ìkùukùu, tabi tí ó lè tú omi inú ìkùukùu dà sílẹ̀,
38 nígbà tí ilẹ̀ bá gbẹ, tóbẹ́ẹ̀ tí ó dì, tí ó sì le koko?
39 “Ṣé o lè wá oúnjẹ fún kinniun, tabi kí o fi oúnjẹ tẹ́ àwọn ọ̀dọ́ kinniun lọ́rùn,
40 nígbà tí wọ́n bá dùbúlẹ̀ ninu ihò wọn, tabi tí wọ́n ba ní ibùba wọn?
41 Ta ní ń wá oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ wọn bá kígbe sí Ọlọrun, tí wọ́n sì ń káàkiri tí wọn ń wá oúnjẹ?
1 “Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ṣé o ti ká àgbọ̀nrín mọ́ ibi tí ó ti ń bímọ rí?
2 Ǹjẹ́ o lè ka iye oṣù tí wọ́n fi ń lóyún? Tabi o mọ ìgbà tí wọ́n bímọ?
3 Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀, tí wọ́n sì bímọ?
4 Àwọn ọmọ wọn á di alágbára, wọn á dàgbà ninu pápá, wọn á sì lọ, láìpadà wá sọ́dọ̀ àwọn òbí wọn mọ́.
5 “Ta ló fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ lómìnira tí ó sì tú ìdè rẹ̀?
6 Mo fi inú pápá ṣe ilé rẹ̀, ilẹ̀ oníyọ̀ sì di ibùgbé rẹ̀.
7 Ó ń pẹ̀gàn ìdàrúdàpọ̀ inú ìlú ńlá, kò gbọ́ ariwo àwọn tí wọn ń fi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ṣiṣẹ́.
8 Ó ń rìn káàkiri àwọn òkè bí ibùjẹ rẹ̀, ó sì ń wá ewéko tútù kiri.
9 “Ṣé ẹfọ̀n ṣetán láti sìn ọ́? Ṣé yóo wá sùn ní ibùjẹ ẹran rẹ lálẹ́?
10 Ṣé o lè so àjàgà mọ́ ọn lọ́rùn ní poro oko, tabi kí ó máa kọ ebè tẹ̀lé ọ?
11 Ṣé o lè gbẹ́kẹ̀lé e nítorí pé agbára rẹ̀ pọ̀, tabi kí o fi iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ fún un láti ṣe?
12 Ṣé o ní igbagbọ pé yóo pada, ati pé yóo ru ọkà rẹ̀ wá sí ibi ìpakà rẹ?
13 “Ògòǹgò lu ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ninu ọláńlá rẹ̀, ṣugbọn kò lè fò bí ẹyẹ àkọ̀?
14 Ó yé ẹyin rẹ̀ sórí ilẹ̀, kí ooru ilẹ̀ lè mú wọn,
15 ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́, ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn.
16 Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀, ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn, kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;
17 nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.
18 Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré, a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́.
19 “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára, tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?
20 Ṣé ìwọ lò ń mú kí ó máa ta pọ́nún bí eṣú, tí kíké rẹ̀ sì ń bani lẹ́rù?
21 Ó fẹsẹ̀ walẹ̀ ní àfonífojì, ó yọ̀ ninu agbára rẹ̀, ó sì jáde lọ sí ojú ogun.
22 Kò mọ ẹ̀rù, ọkàn rẹ̀ kì í rẹ̀wẹ̀sì, bẹ́ẹ̀ ni kì í sá fún idà.
23 Ó gbé apó ọfà sẹ́yìn, tí ń mì pẹkẹpẹkẹ, pẹlu ọ̀kọ̀ tí ń kọ mànà, ati apata.
24 Ó ń fi ẹnu họlẹ̀ pẹlu ìgboyà ati ìwàǹwára, nígbà tí ipè dún, ara rẹ̀ kò balẹ̀.
25 Nígbà tí fèrè dún, ó kọ, ‘Hàáà!’ Ó ń gbóòórùn ogun lókèèrè, ó ń gbọ́ igbe ọ̀gágun tí ń pàṣẹ.
26 “Ṣé ìwọ lo kọ́ àwòdì bí a ti í fò, tí ó fi na ìyẹ́ rẹ̀ sí ìhà gúsù?
27 Ṣé ìwọ ni o pàṣẹ fún idì láti fò lọ sókè, tabi láti tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sórí òkè gíga?
28 Ó kọ́ ilé rẹ̀ sórí òkè gíga-gíga, ninu pàlàpálá àpáta.
29 Níbẹ̀ ni ó ti ń ṣọ́ ohun tí yóo pa, ojú rẹ̀ a sì rí i láti òkèèrè réré.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa mu ẹ̀jẹ̀, ibi tí òkú bá sì wà ni idì máa ń wà.”
1 OLUWA tún sọ fún Jobu pé,
2 “Ṣé ẹni tí ń bá eniyan rojọ́ lè bá Olodumare rojọ́? Kí ẹni tí ń bá Ọlọrun jiyàn dáhùn.”
3 Nígbà náà ni Jobu dá OLUWA lóhùn, ó ní:
4 “OLUWA, kí ni mo jámọ́, tí n óo fi dá ọ lóhùn? Nítorí náà, mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
5 Mo ti sọ̀rọ̀ ju bí ó ti yẹ lọ, n kò sì ní sọ̀rọ̀ mọ́.”
6 Nígbà náà ni OLUWA tún bá Jobu sọ̀rọ̀ láti inú ìjì líle, ó ní,
7 “Múra gírí bí ọkunrin, mo ní ìbéèrè láti bi ọ́, o óo sì dá mi lóhùn.
8 Ṣé o fẹ́ sọ pé mò ń ṣe àìdára ni? O fẹ́ dá mi lẹ́bi kí á lè dá ọ láre?
9 Ṣé o lágbára bí èmi Ọlọrun, àbí o lè sán wàá bí ààrá, nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀?
10 Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, fi ọlá ati ìyìn ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́, kí o sì fi ògo ati ẹwà bo ara rẹ bí aṣọ.
11 Fi ibinu rẹ hàn, wo gbogbo àwọn agbéraga, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
12 Wo gbogbo àwọn agbéraga, kí o sì sọ wọ́n di yẹpẹrẹ, rún àwọn ẹni ibi mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ papọ̀, dì wọ́n ní ìgbèkùn sí ipò òkú.
14 Nígbà náà ni n óo gbà pé, agbára rẹ lè fún ọ ní ìṣẹ́gun.
15 “Wo Behemoti, ẹran ńlá inú omi, tí mo dá gẹ́gẹ́ bí mo ti dá ọ, koríko ni ó ń jẹ bíi mààlúù!
16 Wò ó bí ó ti lágbára tó! Ati irú okun tí awọ inú rẹ̀ ní.
17 Ìrù rẹ̀ dúró ṣánṣán bí igi kedari, gbogbo iṣan itan rẹ̀ dì pọ̀.
18 Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá idẹ, ọwọ́ ati ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí irin.
19 “Ó wà lára àwọn ohun àkọ́kọ́ tí èmi Ọlọrun dá, sibẹ ẹlẹ́dàá rẹ̀ nìkan ló lè pa á.
20 Orí àwọn òkè ni ó ti ń rí oúnjẹ jẹ, níbi tí àwọn ẹranko ìgbẹ́ ti ń ṣeré.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lotusi, lábẹ́ ọ̀pá ìyè ninu ẹrẹ̀.
22 Igi lotusi ni ó ń ṣíji bò ó, igi tí ó wà létí odò yí i ká.
23 Kò náání ìgbì omi, kò bẹ̀rù bí odò Jọdani tilẹ̀ ru dé bèbè rẹ̀.
24 Ṣé eniyan lè fi ìwọ̀ mú un? Tabi kí á fi ọ̀kọ̀ lu ihò sí imú rẹ̀?
1 “Ṣé o lè fi ìwọ̀ fa Lefiatani jáde, tabi kí o fi okùn di ahọ́n rẹ̀?
2 Ṣé o lè fi okùn sí imú rẹ̀, tabi kí o fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní àgbọ̀n?
3 Ṣé yóo bẹ̀ ọ́, tabi kí ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá ọ sọ̀rọ̀?
4 Ṣé yóo bá ọ dá majẹmu, pé kí o fi òun ṣe iranṣẹ títí lae?
5 Ṣé o lè máa fi ṣeré bí ọmọ ẹyẹ, tabi kí o dè é lókùn fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ?
6 Ṣé àwọn oníṣòwò lè yọwó rẹ̀? Àbí wọ́n lè pín Lefiatani láàrin ara wọn?
7 Ṣé o lè fi ọ̀kọ̀ gún ẹran ara rẹ̀, tabi kí o fi ẹ̀sín àwọn apẹja gún orí rẹ̀?
8 Lọ fọwọ́ kàn án; kí o wo irú ìjà tí yóo bá ọ jà; o kò sì ní dán irú rẹ̀ wò mọ́ lae!
9 “Ìrètí ẹni tí ó bá fẹ́ bá a jà yóo di òfo, nítorí ojora yóo mú un nígbà tí ó bá rí i.
10 Ta ló láyà láti lọ jí i níbi tí ó bá sùn sí? Ta ló tó kò ó lójú?
11 Ta ni mo gba nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀ tí mo níláti dá a pada fún un? Kò sí olúwarẹ̀ ní gbogbo ayé.
12 “N kò ní yé sọ̀rọ̀ nípa ẹsẹ̀ rẹ̀, tabi nípa agbára rẹ̀ tabi dídára ìdúró rẹ̀.
13 Ta ló tó bó awọ rẹ̀, tabi kí ó fi nǹkan gún igbá ẹ̀yìn rẹ̀?
14 Ta ló tó ya ẹnu rẹ̀? Gbogbo eyín rẹ̀ ni ó kún fún ẹ̀rù.
15 Ẹ̀yìn rẹ̀ kún fún ìpẹ́ tí ó dàbí apata, a tò wọ́n lẹ́sẹẹsẹ, wọ́n súnmọ́ ara wọn pẹ́kípẹ́kí bí èdìdì.
16 Àwọn ìpẹ́ náà lẹ̀ mọ́ ara wọn tímọ́tímọ́, tóbẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́ kò lè fẹ́ kọjá láàrin wọn.
17 Wọ́n so pọ̀, wọ́n lẹ̀ mọ́ ara wọn tóbẹ́ẹ̀, tí ohunkohun kò lè ṣí wọn.
18 Bí ó bá sín, ìmọ́lẹ̀ á tàn jáde ní imú rẹ̀, ojú rẹ̀ ń tàn bíi ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ kutukutu.
19 Ahọ́n iná ń yọ lẹ́nu rẹ̀ bí iná tí ń ta jáde, bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n iná ń yọ lálá.
20 Èéfín ń jáde ní imú rẹ̀, bíi ti ìkòkò gbígbóná ati ìgbẹ́ tí ń jó.
21 Èémí tí ó ń mí jáde dàbí ògúnná, ahọ́n iná ń yọ ní ẹnu rẹ̀.
22 Kìkì agbára ni ọrùn rẹ̀, ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.
23 Ìṣẹ́po ẹran ara rẹ̀ lẹ̀ pọ̀ mọ́ ara wọn, wọ́n lẹ̀ pọ̀, wọn kò sì ṣe é ṣí.
24 Ọkàn rẹ̀ le bí òkúta, ó le ju ọlọ lọ.
25 Bí ó bá dìde, ẹ̀rù á ba àwọn alágbára, wọn á bì sẹ́yìn, wọn á ṣubú lé ara wọn lórí.
26 Bí idà tilẹ̀ bá a, kò ràn án, bẹ́ẹ̀ náà ni ọ̀kọ̀, ati ọfà, ati ẹ̀sín.
27 Irin kò yàtọ̀ sí koríko lójú rẹ̀, idẹ sì dàbí igi tí ó ti rà.
28 Bí wọn ta á lọ́fà, kò ní torí rẹ̀ sá, àwọn òkúta kànnàkànnà dàbí àgékù koríko lójú rẹ̀.
29 Kùmọ̀ dàbí koríko lára rẹ̀, a sì máa fi ẹni tí ó ju ọ̀kọ̀ lù ú rẹ́rìn-ín.
30 Ìpẹ́ ikùn rẹ̀ dàbí àpáàdì tí ó mú, wọn ń fa ilẹ̀ tútù ya bí ọkọ́.
31 Ó mú kí ibú hó bí omi inú ìkòkò, ó ṣe òkun bí ìkòkò òróró ìpara.
32 Bí ó bá ń rìn lọ, ipa ọ̀nà rẹ̀ a máa hàn lẹ́yìn rẹ̀, eniyan á rò pé òkun ń hó bí ọṣẹ ni.
33 Kò sí ohun tí a lè fi wé láyé, ẹ̀dá tí ẹ̀rù kì í bà.
34 Ó fojú tẹmbẹlu gbogbo ohun gíga, ó sì jọba lórí gbogbo àwọn ọmọ agbéraga.”
1 Jobu bá dá OLUWA lóhùn ó ní:
2 “Mo mọ̀ pé o lè ṣe ohun gbogbo, kò sì sí ohun tí ó lè da ìpinnu rẹ rú.
3 Ta nìyí tí ń fi ìmọ̀ràn pamọ́ láìní òye? Àwọn ohun tí mo sọ kò yé mi, ìyanu ńlá ni wọ́n jẹ́ fún mi, n kò sì mọ̀ wọ́n.
4 O ní kí n tẹ́tí sílẹ̀, nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀, kí n sì dáhùn nígbà tí o bá bèèrè nǹkan lọ́wọ́ mi.
5 Ìró rẹ ni mo gbọ́ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn nisinsinyii mo ti rí ọ;
6 nítorí náà, ojú ara mi tì mí, fún ohun tí mo ti sọ, mo sì ronupiwada ninu erùpẹ̀ ati eérú.”
7 Lẹ́yìn ìgbà tí OLUWA ti bá Jobu sọ̀rọ̀ tán, ó sọ fún Elifasi ará Temani pé, “Inú ń bí mi sí ìwọ ati àwọn ọ̀rẹ́ rẹ mejeeji. Nítorí ẹ kò sọ ohun tí ó tọ́ nípa mi, bí Jobu iranṣẹ mi ti ṣe.
8 Nítorí náà, mú akọ mààlúù meje ati àgbò meje lọ sí ọ̀dọ̀ Jobu kí o rú ẹbọ sísun fún ara rẹ; Jobu iranṣẹ mi yóo sì gbadura fún ọ, n óo gbọ́ adura rẹ̀, n kò sì ní ṣe sí ọ gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ. Nítorí o kò sọ ohun tí ó tọ́ nípa mi gẹ́gẹ́ bí Jobu iranṣẹ mi ti ṣe.”
9 Nítorí náà, Elifasi ará Temani, Bilidadi ará Ṣuha, ati Sofari ará Naama lọ ṣe ohun tí OLUWA sọ fún wọn, OLUWA sì gbọ́ adura Jobu.
10 Lẹ́yìn ìgbà tí Jobu gbadura fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ mẹtẹẹta tán, OLUWA dá ọrọ̀ Jobu pada, ó sì jẹ́ kí ó ní ìlọ́po meji àwọn ohun tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
11 Àwọn arakunrin ati arabinrin Jobu ati àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀ tẹ́lẹ̀ pada wá bẹ̀ ẹ́ wò. Wọ́n jẹ àsè ní ilé rẹ̀, wọ́n káàánú rẹ̀, wọ́n sì tù ú ninu, nítorí ohun burúkú tí OLUWA ti mú wá sórí rẹ̀, olukuluku wọn fún un ní owó ati òrùka wúrà kọ̀ọ̀kan.
12 OLUWA bukun ìgbẹ̀yìn Jobu ju ti iṣaaju rẹ̀ lọ, ó ní ẹgbaaje (14,000) aguntan, ẹgbaata (6,000) ràkúnmí, ẹgbẹrun (1,000) àjàgà mààlúù ati ẹgbẹrun (1,000) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
13 Ó tún bí ọmọkunrin meje ati ọmọbinrin mẹta.
14 Ó pe àkọ́bí obinrin ni Jemima, ekeji ni Kesaya, ẹkẹta ni Kereni Hapuki.
15 Kò sì sí ọmọbinrin tí ó lẹ́wà bí àwọn ọmọbinrin Jobu ní gbogbo ayé. Baba wọn sì fún wọn ní ogún láàrin àwọn arakunrin wọn.
16 Lẹ́yìn náà Jobu tún gbé ogoje (140) ọdún sí i láyé, ó rí àwọn ọmọ ati àwọn ọmọ-ọmọ rẹ̀ títí dé ìran kẹrin.
17 Ó di arúgbó kùjọ́kùjọ́ kí ó tó kú.