1

1 Àwọn òwe tí Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli pa,

2 kí àwọn eniyan lè ní ọgbọ́n ati ẹ̀kọ́, kí òye ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ lè yé wọn,

3 láti gba ẹ̀kọ́, tí yóo kọ́ni lọ́gbọ́n, òdodo, ẹ̀tọ́ ati àìṣojúṣàájú,

4 láti kọ́ onírẹ̀lẹ̀ lọ́gbọ́n, kí á sì fi ìmọ̀ ati làákàyè fún ọ̀dọ́,

5 kí ọlọ́gbọ́n lè gbọ́, kí ó sì fi ìmọ̀ kún ìmọ̀ rẹ̀, kí ẹni tí ó ní òye lè ní ìmọ̀ pẹlu.

6 Láti lè mọ òwe ati àkàwé ọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ati àdììtú ọ̀rọ̀.

7 Ìbẹ̀rù OLUWA ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ a máa pẹ̀gàn ọgbọ́n ati ẹ̀kọ́.

8 Ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ẹ̀kọ́ baba rẹ, má sì kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ,

9 nítorí pé ẹ̀kọ́ tí wọn bá kọ́ ọ yóo dàbí adé tí ó lẹ́wà lórí rẹ, ati bí ohun ọ̀ṣọ́ ní ọrùn rẹ.

10 Ìwọ ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, o ò gbọdọ̀ gbà.

11 Bí wọn bá wí pé, “Tẹ̀lé wa ká lọ, kí á lọ sápamọ́ láti paniyan, kí á lúgọ de aláìṣẹ̀,

12 jẹ́ kí á gbé wọn mì láàyè kí á gbé wọn mì lódidi bí isà òkú,

13 a óo rí àwọn nǹkan olówó iyebíye kó, ilé wa yóo sì kún fún ìkógun.

14 Ìwọ ṣá darapọ̀ mọ́ wa, kí á sì jọ lẹ̀dí àpò pọ̀.”

15 Ọmọ mi, má bá wọn kẹ́gbẹ́, má sì bá wọn rìn,

16 nítorí ọ̀nà ibi ni ẹsẹ̀ wọn máa ń yá sí, wọ́n a sì máa yára láti paniyan.

17 Asán ni àwọ̀n tí eniyan dẹ sílẹ̀, nígbà tí ẹyẹ tí a dẹ ẹ́ fún ń woni,

18 ṣugbọn ẹ̀jẹ̀ ara wọn ni irú àwọn eniyan bẹ́ẹ̀ lúgọ dè, ìparun ẹ̀mí ara wọn ni wọ́n lúgọ tí wọn ń retí.

19 Bẹ́ẹ̀ ni ti àwọn tí wọ́n ń fi ipá kó ọrọ̀ jọ rí, ọrọ̀ tí wọn fi ipá kójọ níí gba ẹ̀mí wọn.

20 Ọgbọ́n ń kígbe ní òpópónà, ó ń pariwo láàrin ọjà,

21 ó ń kígbe lórí odi ìlú, ó ń sọ̀rọ̀ ní àwọn ẹnubodè ìlú, ó ní,

22 “Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ óo ti pẹ́ tó ninu àìmọ̀kan yín? Àwọn pẹ̀gànpẹ̀gàn yóo ti ní inú dídùn pẹ́ tó ninu ẹ̀gàn pípa wọn, tí àwọn òmùgọ̀ yóo sì kórìíra ìmọ̀?

23 Ẹ fetí sí ìbáwí mi, n óo ṣí ọkàn mi payá fun yín, n óo sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mi ye yín.

24 Nítorí pé mo ti ké títí, kò sì sí ẹni tí ó gbọ́, mo ti na ọwọ́ si yín ṣugbọn kò sí ẹni tí ó dá mi lóhùn,

25 ẹ ti pa gbogbo ìmọ̀ràn mi tì, ẹ kò sì gbọ́ ọ̀kankan ninu ìbáwí mi.

26 Èmi náà óo sì máa fi yín rẹ́rìn-ín nígbà tí ìdààmú bá dé ba yín, n óo máa fi yín ṣe ẹlẹ́yà nígbà tí ìpayà bá dé ba yín.

27 Nígbà tí ìpayà bá dé ba yín bí ìjì, tí ìdààmú dé ba yín bí ìjì líle, tí ìpọ́njú ati ìrora bò yín mọ́lẹ̀.

28 Ẹ óo ké pè mí nígbà náà, ṣugbọn n kò ní dáhùn. Ẹ óo wá mi láìsinmi, ṣugbọn ẹ kò ní rí mi.

29 Nítorí pé ẹ kórìíra ìmọ̀, ẹ kò sì bẹ̀rù OLUWA.

30 Ẹ kò fẹ́ ìmọ̀ràn mi, ẹ sì kẹ́gàn gbogbo ìbáwí mi.

31 Nítorí náà, ẹ óo jèrè iṣẹ́ yín, ìwà burúkú yín yóo sì di àìsàn si yín lára.

32 Àwọn aláìgbọ́n kú nítorí pé wọn kò gba ẹ̀kọ́ aibikita àwọn òmùgọ̀ ni yóo pa wọ́n run.

33 Ṣugbọn ẹni tí ó gbọ́ tèmi, yóo máa wà láìléwu, yóo máa gbé pẹlu ìrọ̀rùn, láìsí ìpayà ibi.”

2

1 Ọmọ mi, bí o bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí o sì pa òfin mi mọ́,

2 tí o bá ń tẹ́tí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n, tí o sì fi ọkàn sí òye,

3 bí o bá kígbe tí o tọrọ òye tí ó jinlẹ̀, tí o gbóhùn sókè tí o bèèrè ìmọ̀,

4 bí o bá wá ọgbọ́n bí ẹni ń wá fadaka, tí o sì wá a bí ẹni ń wá ìṣúra tí a pamọ́,

5 nígbà náà ni ìbẹ̀rù OLUWA yóo yé ọ. O óo sì rí ìmọ̀ Ọlọrun.

6 Nítorí OLUWA níí fún ni ní ọgbọ́n, ẹnu rẹ̀ sì ni òye ati ìmọ̀ ti ń wá.

7 Ó fún àwọn tí wọn dúró ṣinṣin ní ìjìnlẹ̀ ọgbọ́n, òun ni ààbò fún àwọn tí wọ́n ń rin ọ̀nà ẹ̀tọ́.

8 Ó ń tọ́ wọn sí ìdájọ́ òtítọ́, ó sì ń pa ọ̀nà àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀ mọ́.

9 Nígbà náà ni ìtumọ̀ òdodo ati ẹ̀tọ́ yóo yé ọ ati àìṣe ojuṣaaju, ati gbogbo ọ̀nà rere.

10 Nítorí ọgbọ́n yóo wọnú ọkàn rẹ, ìmọ̀ yóo sì tu ẹ̀mí rẹ lára,

11 ọgbọ́n inú yóo máa ṣọ́ ọ, òye yóo sì máa dáàbò bò ọ́,

12 yóo máa gbà ọ́ lọ́wọ́ ibi ṣíṣe, ati lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́tàn,

13 àwọn tí wọ́n ti kọ ọ̀nà òdodo sílẹ̀ tí wọn sì ń rìn ninu òkùnkùn;

14 àwọn tí wọn ń yọ̀ ninu ìwà ibi tí wọ́n sì ní inú dídùn sí ìyapa ibi;

15 àwọn tí ọ̀nà wọn wọ́, tí wọ́n kún fún ìwà àrékérekè.

16 A óo gbà ọ́ lọ́wọ́ obinrin oníṣekúṣe, àní lọ́wọ́ obinrin onírìnkurìn pẹlu ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn rẹ̀.

17 Ẹni tí ó kọ ọkọ àárọ̀ rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbàgbé majẹmu Ọlọrun rẹ̀.

18 Ẹni tí ilé rẹ̀ rì sinu ìparun, tí ọ̀nà rẹ̀ sì wà ninu ọ̀fìn isà òkú.

19 Kò sí ẹni tí ó tọ̀ ọ́ lọ, tí ó pada rí, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í tún pada sí ọ̀nà ìyè.

20 Nítorí náà, máa rìn ní ọ̀nà àwọn eniyan rere, sì máa bá àwọn olódodo rìn.

21 Nítorí àwọn tí wọ́n dúró ṣinṣin ni wọn yóo máa gbé ilẹ̀ náà, àwọn olóòótọ́ inú ni yóo máa wà níbẹ̀,

22 ṣugbọn a óo pa ẹni ibi run lórí ilẹ̀ náà, a óo sì fa alárèékérekè tu kúrò níbẹ̀.

3

1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ tí mo kọ́ ọ, sì pa òfin mi mọ́ lọ́kàn rẹ,

2 nítorí wọn óo fún ọ ní ẹ̀mí gígùn ati ọpọlọpọ alaafia.

3 Má jẹ́ kí ìwà ìṣòótọ́ kí ó fi ọ́ sílẹ̀, so àánú ati òtítọ́ mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí oókan àyà rẹ.

4 Nípa bẹ́ẹ̀, o óo rí ojurere ati iyì lọ́dọ̀ Ọlọrun ati eniyan.

5 Fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, má sì tẹ̀lé ìmọ̀ ara rẹ.

6 Mọ Ọlọrun ní gbogbo ọ̀nà rẹ, yóo sì mú kí ọ̀nà rẹ tọ́.

7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara rẹ, bẹ̀rù OLUWA, kí o sì yẹra fún ibi.

8 Tí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóo jẹ́ ìwòsàn fún ara rẹ, ati ìtura fún egungun rẹ.

9 Fi ohun ìní rẹ bọ̀wọ̀ fún OLUWA pẹlu gbogbo àkọ́so oko rẹ.

10 Nígbà náà ni àká rẹ yóo kún bámúbámú, ìkòkò waini rẹ yóo sì kún àkúnya.

11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìtọ́ni OLUWA, má sì ṣe jẹ́ kí ìbáwí rẹ̀ sú ọ.

12 Nítorí ẹni tí OLUWA bá fẹ́ níí báwí gẹ́gẹ́ bí baba tí máa ń bá ọmọ rẹ̀ tí ó bá fẹ́ràn wí.

13 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó wá ọgbọ́n rí, ati ẹni tí ó ní òye.

14 Nítorí èrè rẹ̀ dára ju èrè orí fadaka ati ti wúrà lọ.

15 Ọgbọ́n níye lórí ó ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ, kò sí ohun tí o lè fi wé e, ninu gbogbo ohun tí ọkàn rẹ lè fẹ́.

16 Ẹ̀mí gígùn wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ọrọ̀ ati iyì sì wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀.

17 Ọ̀nà rẹ̀ tura pupọ, alaafia sì ni gbogbo ọ̀nà rẹ̀.

18 Igi ìyè ni fún àwọn tí wọ́n rọ̀ mọ́ ọn, ayọ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí wọ́n dì í mú ṣinṣin.

19 Ọgbọ́n ni OLUWA fi fi ìdí ayé sọlẹ̀, òye ni ó sì fi dá ọ̀run.

20 Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ni ibú fi ń tú omi jáde, tí ìrì fi ń sẹ̀ láti inú ìkùukùu.

21 Ọmọ mi, di ọgbọ́n tí ó yè kooro ati làákàyè mú, má sì ṣe jẹ́ kí wọn bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ,

22 wọ́n yóo jẹ́ ìyè fún ẹ̀mí rẹ, ati ohun ọ̀ṣọ́ ní ọrùn rẹ.

23 Nígbà náà ni o óo máa rìn láìléwu ati láìkọsẹ̀.

24 Bí o bá jókòó, ẹ̀rù kò ní bà ọ́, bí o bá sùn, oorun yóo máa dùn mọ́ ọ.

25 Má bẹ̀rù àjálù òjijì, tabi ìparun àwọn ẹni ibi, nígbà tí ó bá dé bá ọ,

26 nítorí pé, OLUWA ni igbẹkẹle rẹ, kò sì ní jẹ́ kí o ti ẹsẹ̀ bọ tàkúté.

27 Má ṣe fa ọwọ́ ire sẹ́yìn lọ́dọ̀ àwọn tí ó tọ́ sí, nígbà tí ó bá wà ní ìkáwọ́ rẹ láti ṣe é.

28 Má sọ fún aládùúgbò rẹ pé, “Máa lọ ná, n óo fún ọ tí o bá pada wá lọ́la,” nígbà tí ohun tí ó fẹ́ wà lọ́dọ̀ rẹ.

29 Má ṣe gbèrò ibi sí aládùúgbò rẹ tí ń fi inú kan bá ọ gbé.

30 Má ṣe bá ẹnikẹ́ni jà láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ níbi.

31 Má ṣe ìlara ẹni ibi má sì ṣe tẹ̀ sí èyíkéyìí ninu àwọn ọ̀nà rẹ̀.

32 Nítorí OLUWA kórìíra alárèékérekè, ṣugbọn ó ní igbẹkẹle ninu àwọn tí wọn dúró ṣinṣin.

33 Ègún OLUWA wà lórí ìdílé ẹni ibi, ṣugbọn a máa bukun ibùgbé àwọn olódodo.

34 A máa fi àwọn pẹ̀gànpẹ̀gàn ṣe ẹlẹ́yà, ṣugbọn a máa fi ojurere wo àwọn onírẹ̀lẹ̀.

35 Ọlọ́gbọ́n yóo jogún iyì, ṣugbọn ojú yóo ti òmùgọ̀.

4

1 Ẹ̀yin ọmọ, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ baba yín, ẹ tẹ́tí sílẹ̀, kí ẹ lè ní ìmọ̀,

2 nítorí pé mo fun yín ní ìlànà rere, ẹ má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi.

3 Nígbà tí mo wà ní ọmọde lọ́dọ̀ baba mi, tí mo jẹ́ ẹni ìkẹ́, ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi,

4 baba mi kọ́ mi, ó ní, “Fi ọ̀rọ̀ mi sọ́kàn, pa òfin mi mọ́, kí o lè wà láàyè.

5 Jẹ́ ọlọ́gbọ́n kí o sì ní ìmọ̀. Má gbàgbé, má sì kọ ọ̀rọ̀ sí mi lẹ́nu.

6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóo pa ọ́ mọ́, fẹ́ràn rẹ̀, yóo sì dáàbò bò ọ́.

7 Bí o bá fẹ́ gbọ́n, bẹ̀rẹ̀ sí kọ́gbọ́n, ohun yòówù tí o lè tún ní, ọgbọ́n ló jù, nítorí náà jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

8 Gbé ọgbọ́n lárugẹ, yóo sì gbé ọ ga, yóo bu ọlá fún ọ, bí o bá gbà á mọ́ra.

9 Yóo fi nǹkan ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà bò ọ́ lórí, yóo sì dé ọ ní adé dáradára.”

10 Gbọ́, ọmọ mi, gba ẹ̀kọ́ mi, kí ẹ̀mí rẹ lè gùn.

11 Mo ti kọ́ ọ ní ọgbọ́n, mo sì ti fẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà òtítọ́.

12 Nígbà tí o bá ń rìn, o kò ní rí ìdínà, nígbà tí o bá ń sáré, o kò ní fi ẹsẹ̀ kọ.

13 Di ẹ̀kọ́ mú ṣinṣin, má jẹ́ kí ó bọ́, pa á mọ́, nítorí òun ni ìyè rẹ.

14 Má ṣe gba ọ̀nà ẹni ibi, má sì ṣe rin ọ̀nà eniyan burúkú.

15 Yẹra fún un, má tilẹ̀ kọjú sí ọ̀nà ibẹ̀, ṣugbọn gba ibòmíràn, kí o máa bá tìrẹ lọ.

16 Nítorí wọn kì í lè é sùn, bí wọn kò bá tíì ṣe ibi, oorun kì í kùn wọ́n, tí wọn kò bá tíì fa ìṣubú eniyan.

17 Ìkà ṣíṣe ni oúnjẹ wọn, ìwà ipá sì ni ọtí waini wọn.

18 Ṣugbọn ọ̀nà olódodo dàbí ìmọ́lẹ̀ àfẹ̀mọ́júmọ́, tí ń mọ́lẹ̀ sí i láti ìdájí títí tí ilẹ̀ yóo fi mọ́ kedere.

19 Ọ̀nà eniyan burúkú dàbí òkùnkùn biribiri, wọn kò mọ ohun tí wọn yóo dìgbò lù.

20 Ọmọ mi, fetí sí ọ̀rọ̀ mi, tẹ́tí sílẹ̀ sí ohun tí mò ń sọ.

21 Má jẹ́ kí wọn rú ọ lójú, fi wọ́n sọ́kàn.

22 Nítorí pé ìyè ni wọ́n jẹ́ fún àwọn tí ó rí wọn, ati ìwòsàn fún gbogbo ẹran ara wọn.

23 Ṣọ́ra pẹlu èrò ọkàn rẹ, nítorí èrò ọkàn ni orísun ìyè.

24 Má lọ́wọ́ ninu ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ, sì jìnnà sí ọ̀rọ̀ àgàbàgebè.

25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán, kí o sì kọjú sí ibi tí ò ń lọ tààrà.

26 Kíyèsí ìrìn ẹsẹ̀ rẹ, gbogbo ọ̀nà rẹ yóo sì là.

27 Má ṣe yà sí ọ̀tún tabi sí òsì, yipada kúrò ninu ibi.

5

1 Ọmọ mi fetí sí ọgbọ́n tí mò ń kọ́ ọ, tẹ́tí rẹ sí òye mi,

2 kí o baà lè ní làákàyè, kí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ lè kún fún ìmọ̀.

3 Nítorí ẹnu alágbèrè obinrin a máa dùn bí oyin, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì tuni lára ju òróró lọ,

4 ṣugbọn níkẹyìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ á korò bí iwọ, ẹnu rẹ̀ á sì mú bí idà olójú meji.

5 Ẹsẹ̀ rẹ̀ ń dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ lọ sinu ikú, ìgbésẹ̀ rẹ̀ sì lọ tààrà sinu ibojì.

6 Ó kọ̀ láti rin ọ̀nà ìyè, ọ̀nà rẹ̀ wọ́, kò sì mọ̀.

7 Nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, ẹ má sì kọ ọ̀rọ̀ sí mi lẹ́nu.

8 Ẹ jìnnà sí alágbèrè obinrin, kí ẹ má tilẹ̀ súnmọ́ ẹnu ọ̀nà rẹ̀,

9 kí ẹ má baà gbé ògo yín fún ẹlòmíràn, kí ẹ sì fi ìgbé ayé yín lé aláìláàánú lọ́wọ́.

10 Kí àjèjì má baà jèrè iṣẹ́ yín, kí làálàá rẹ má sì bọ́ sápò àlejò.

11 Kí o má baà kérora nígbẹ̀yìn ayé rẹ, nígbà tí o bá di ìjẹ fún ẹni ẹlẹ́ni

12 nígbà náà ni o óo wí pé, “Kí ló dé tí mo kórìíra ìtọ́ni, tí ọkàn mi sì kẹ́gàn ìbáwí!

13 N kò fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn olùkọ́ mi n kò sì gba ti àwọn tí wọn ń tọ́ mi sọ́nà.

14 Èyí ni ó sún mi dé etí bèbè ìparun, láàrin àwùjọ eniyan.”

15 Ìwọ ọkọ, láti inú àmù rẹ ni kí o ti máa mu omi; omi tí ń sun láti inú kànga rẹ ni kí o máa mu.

16 Kò dára kí orísun rẹ máa ṣàn káàkiri, bí omi àgbàrá ní gbogbo òpópónà.

17 Tìrẹ nìkan ṣoṣo ni kí ó jẹ́, má jẹ́ kí àjèjì bá ọ pín ninu rẹ̀.

18 Jẹ́ kí orísun rẹ ní ibukun, kí inú rẹ sì máa dùn sí iyawo tí o fi àárọ̀ gbé.

19 Olólùfẹ́ rẹ tí ó dára bí abo egbin. Jẹ́ kí ẹwù rẹ̀ máa mú inú rẹ dùn nígbà gbogbo, kí ìfẹ́ rẹ̀ máa mú orí rẹ yá nígbàkúùgbà.

20 Kí ló dé, ọmọ mi, tí ìfẹ́ alágbèrè obinrin yóo fi wọ̀ ọ́ lọ́kàn, tí o óo fi máa dìrọ̀ mọ́ obinrin olobinrin?

21 Nítorí OLUWA rí gbogbo ohun tí eniyan ń ṣe, ó sì ń ṣàkíyèsí gbogbo ìrìn rẹ̀.

22 Eniyan burúkú a máa jìn sinu ọ̀fìn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a sì bọ́ sinu ìyọnu nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

23 Yóo kú nítorí àìgba ìtọ́ni, yóo sì sọnù nítorí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.

6

1 Ọmọ mi, bí o bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, tí o jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì,

2 tí o bá bọ́ sinu tàkúté tí o fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ dẹ fún ara rẹ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ sì ti kó bá ọ,

3 o ti bọ́ sọ́wọ́ aládùúgbò rẹ. Nítorí náà báyìí ni kí o ṣe, ọmọ mi, kí o lè gba ara rẹ là: lọ bá a kíákíá, kí o sì bẹ̀ ẹ́.

4 Má sùn, má sì tòògbé,

5 gba ara rẹ sílẹ̀ bí àgbọ̀nrín tíí gba ara rẹ̀ sílẹ̀ lọ́wọ́ ọdẹ, àní, bí ẹyẹ tíí ṣe, tíí fi í bọ́ lọ́wọ́ pẹyẹpẹyẹ.

6 Ìwọ ọ̀lẹ, tọ èèrùn lọ, ṣàkíyèsí ìṣe rẹ̀, kí o sì kọ́gbọ́n.

7 Ẹ̀dá tí kò ní olórí, tabi alabojuto, tabi aláṣẹ

8 sibẹsibẹ, a máa tọ́jú oúnjẹ rẹ̀ ní àkókò ẹ̀ẹ̀rùn; a sì máa kó oúnjẹ jọ, ní àkókò ìkórè.

9 O óo ti sùn pẹ́ tó, ìwọ ọ̀lẹ? Ìgbà wo ni o óo tají lójú oorun?

10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,

11 yóo jẹ́ kí òṣì dé bá ọ, bí ọlọ́ṣà dé bá eniyan. Àìní yóo sì dé bá ọ bíi jagunjagun dé báni.

12 Eniyan lásán, ìkà eniyan, a máa rìn káàkiri, a máa sọ̀rọ̀ àrékérekè,

13 bí ó ti ń ṣẹ́jú, bẹ́ẹ̀ ni ó ń jansẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ó sì ń fi ìka ṣe àpèjúwe.

14 Ó ń fi inú burúkú pète ibi, ó sì ń fi ojoojumọ dá ìjà sílẹ̀,

15 nítorí náà, ibi yóo dé bá a lójijì, yóo parun kíá láìsí àtúnṣe.

16 Àwọn nǹkan mẹfa kan wà tí OLUWA kò fẹ́: wọ́n tilẹ̀ tó meje tí ó jẹ́ ohun ìríra fún un:

17 Ìgbéraga, irọ́ pípa, ẹni tí ń déédé pa aláìṣẹ̀,

18 ọkàn tí ń pète ìkà, ẹsẹ̀ tí ń sáré sí ibi,

19 ẹlẹ́rìí èké tí ẹnu rẹ̀ kún fún irọ́, ati ẹni tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrin eniyan.

20 Ọmọ mi, pa òfin baba rẹ mọ́, má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21 Fi wọ́n sọ́kàn nígbà gbogbo, kí o sì so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.

22 Nígbà tí o bá ń lọ, wọn yóo máa tọ́ ọ, bí o bá sùn, wọn yóo máa ṣọ́ ọ, bí o bá jí, wọn yóo máa bá ọ sọ̀rọ̀.

23 Nítorí fìtílà ni òfin, ìmọ́lẹ̀ ni ẹ̀kọ́, ìbáwí sì jẹ́ ọ̀nà ìyè,

24 láti pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obinrin burúkú, ati lọ́wọ́ ẹnu alágbèrè obinrin tí ó dùn lọ́rọ̀.

25 Má jẹ́ kí ẹwà rẹ̀ wù ọ́, má sì ṣe jẹ́ kí ó fi ìpéǹpéjú rẹ̀ mú ọ.

26 Owó tí aṣẹ́wó yóo gbà kò ju owó burẹdi lọ, ṣugbọn gbogbo ẹ̀mí rẹ ni alágbèrè yóo fi ọgbọ́n gbà.

27 Ǹjẹ́ ẹnìkan lè gbé iná ka àyà, kí aṣọ rẹ̀ má jó?

28 Tabi eniyan lè rìn lórí ẹ̀yinná, kí iná má jó o lẹ́sẹ̀?

29 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ ẹni tí ó lọ bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀ rí, kò sí ẹni tí yóo ṣe bẹ́ẹ̀ tí yóo lọ láìjìyà.

30 Ẹnìkan kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jí oúnjẹ jẹ nítorí ebi.

31 Sibẹsibẹ, bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, yóo fi san ìlọ́po meje, ó lè jẹ́ pé gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni yóo fi san án.

32 Ẹni tí ó bá ṣe àgbèrè kò lọ́gbọ́n lórí, ẹni tí ó bá dán an wò, ara rẹ̀ ni ó ń parun.

33 Ọgbẹ́ ati àbùkù ni yóo gbà, ìtìjú rẹ̀ kò sì ní kúrò lára rẹ̀ laelae.

34 Nítorí owú jíjẹ a máa mú kí inú ọkọ ru, kò sì ní jẹ́ ṣàánú àlè bó bá di pé à ń gbẹ̀san.

35 Kò ní gba owó ìtanràn, ọpọlọpọ ẹ̀bùn kò sì ní lè tù ú lójú.

7

1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kí o sì fi òfin mi sinu ọkàn rẹ.

2 Pa òfin mi mọ́, kí o lè yè, pa ẹ̀kọ́ mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹyin ojú rẹ,

3 wé wọn mọ́ ìka rẹ, kí o sì kọ wọ́n sí oókan àyà rẹ.

4 Sọ fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arabinrin mi,” kí o sì pe ìmọ̀ ní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn rẹ,

5 kí wọ́n baà lè pa ọ́ mọ́, kúrò lọ́dọ̀ alágbèrè obinrin, ati kúrò lọ́wọ́ onírìnkurìn pẹlu ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀.

6 Mo yọjú wo ìta, láti ojú fèrèsé ilé mi.

7 Mo rí àwọn ọ̀dọ́ tí wọn kò ní ìrírí, mo ṣe akiyesi pé láàrin wọn, ọmọkunrin kan wà tí kò gbọ́n.

8 Ó ń lọ ní òpópónà, lẹ́bàá kọ̀rọ̀ ilé alágbèrè obinrin náà,

9 ní àṣáálẹ́, nígbà tí ọjọ́ ń pofírí, tí ilẹ̀ ti ń ṣú, tí òkùnkùn ti ń kùn.

10 Obinrin kan lọ pàdé rẹ̀, ó wọ aṣọ aṣẹ́wó, ọkàn rẹ̀ kún fún ẹ̀tàn.

11 Ó jẹ́ aláriwo ati onírìnkurìn obinrin, kì í gbélé rẹ̀.

12 Bí ó ti ń rìn kiri lójú pópó, bẹ́ẹ̀ ni yóo máa lọ, tí yóo máa bọ̀ láàrin ọjà, yóo máa dọdẹ kiri ní gbogbo kọ̀rọ̀.

13 Yóo bá dì mọ́ ọmọkunrin tí kò gbọ́n náà, yóo fi ẹnu kò ó lẹ́nu, yóo wí pẹlu ainitiju pé,

14 “Mo ti rú ẹbọ alaafia, mo sì ti san ẹ̀jẹ́ mi lónìí.

15 Nítorí náà, mo wá pàdé rẹ, mo fi ìlara wá ọ, mo sì rí ọ.

16 Mo ti tẹ́ aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ aláràbarà ti ilẹ̀ Ijipti sórí ibùsùn mi.

17 Mo tú turari olóòórùn dídùn ati òjíá, aloe ati sinamoni, sórí ibùsùn mi.

18 Wá, jẹ́ kí á ṣeré ìfẹ́ títí ilẹ̀ yóo fi mọ́, jẹ́ kí á fi ìfẹ́ gbádùn ara wa.

19 Ọkọ mi kò sí nílé, ó ti lọ sí ìrìn àjò, ọ̀nà rẹ̀ sì jìn.

20 Ó mú owó pupọ lọ́wọ́, kò ní dé títí òṣùpá yóo fi di àrànmọ́jú.”

21 Ó rọ̀ ọ́ pẹlu ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, ó fi ọ̀rọ̀ dídùn mú un.

22 Lẹsẹkẹsẹ, ọmọkunrin náà bẹ̀rẹ̀ sí tẹ̀lé e, bíi mààlúù tí wọn ń fà lọ pa, tabi bí àgbọ̀nrín tí ó tẹsẹ̀ bọ tàkúté,

23 títí tí ọfà fi wọ̀ ọ́ ninu bí ẹyẹ tí ń yára bọ́ sinu okùn, láì mọ̀ pé ó lè ṣe ikú pa òun.

24 Nisinsinyii, ẹ fetí sílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ farabalẹ̀ gbọ́ nǹkan tí mò ń sọ.

25 Ẹ má jẹ́ kí ọkàn yín lọ sọ́dọ̀ irú obinrin bẹ́ẹ̀, ẹ má ṣèèṣì yà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

26 Ọ̀pọ̀ ni àwọn tí ó ti sọ di ẹni ilẹ̀, ọpọlọpọ àwọn alágbára ni ó ti ṣe ikú pa.

27 Ọ̀nà isà òkú tààrà ni ilé rẹ̀, ilé rẹ̀ ni ọ̀nà àbùjá sí ìparun.

8

1 Ọgbọ́n ń pe eniyan, òye ń pariwo.

2 Ó dúró ní ibi tí ó ga lẹ́bàá ọ̀nà, ati ní ojú ọ̀nà tóóró,

3 ó ń kígbe lóhùn rara lẹ́nu ibodè àtiwọ ìlú, ó ń ké ní ẹnu ọ̀nà àbáwọlé pẹlu, ó ń wí pé:

4 “Ẹ̀yin eniyan ni mò ń pè, gbogbo ọmọ eniyan ni mò ń ké sí.

5 Ẹ̀yin òpè, ẹ kọ́ ọgbọ́n, ẹ̀yin òmùgọ̀, ẹ fetí sí òye.

6 Ẹ tẹ́tí ẹ gbọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ pataki ni mo fẹ́ sọ. Ohun tí ó tọ́ ni n óo sì fi ẹnu mi sọ.

7 Ọ̀rọ̀ òtítọ́ ni yóo ti ẹnu mi jáde, nítorí mo kórìíra ọ̀rọ̀ burúkú.

8 Òdodo ni gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi, kò sí ìtànjẹ tabi ọ̀rọ̀ àrékérekè ninu wọn.

9 Gbogbo ọ̀rọ̀ náà tọ́ lójú ẹni tí ó mòye, wọn kò sì ní àbùkù lọ́dọ̀ àwọn tí wọ́n ní ìmọ̀.

10 Gba ẹ̀kọ́ mi dípò fadaka, ati ìmọ̀ dípò ojúlówó wúrà,

11 nítorí ọgbọ́n níye lórí ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ, kò sí ohun tí o fẹ́, tí a lè fi wé e.

12 Èmi, ọgbọ́n, òye ni mò ń bá gbélé, mo ṣe àwárí ìmọ̀ ati làákàyè.

13 Ẹni tó bá bẹ̀rù OLUWA, yóo kórìíra ibi, mo kórìíra ìwà ìgbéraga, ọ̀nà ibi ati ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́.

14 Èmi ni mo ní ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n tí ó yè kooro, mo sì ní òye ati agbára.

15 Nípasẹ̀ mi ni àwọn ọba fi ń ṣe ìjọba, tí àwọn alákòóso sì ń pàṣẹ òdodo.

16 Nípasẹ̀ mi ni àwọn olórí ń ṣe àkóso, gbogbo àwọn ọlọ́lá sì ń ṣe àkóso ayé.

17 Mo fẹ́ràn gbogbo àwọn tí wọ́n fẹ́ràn mi, àwọn tí wọ́n bá fi tọkàntọkàn wá mi yóo sì rí mi.

18 Ọrọ̀ ati iyì wà níkàáwọ́ mi, ọrọ̀ tíí tọ́jọ́, ati ibukun.

19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ, àyọrísí mi sì dára ju ojúlówó fadaka lọ.

20 Ọ̀nà òdodo ni èmi ń rìn, ojú ọ̀nà tí ó tọ́ ni mò ń tọ̀.

21 Èmi a máa fún àwọn tí wọ́n fẹ́ mi ní ọrọ̀, n óo máa mú kí ìṣúra wọn kún.

22 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá ayé ni OLUWA ti dá mi, kí ó tó bẹ̀rẹ̀ àwọn iṣẹ́ àrà rẹ̀.

23 Láti ayébáyé ni a ti yàn mí, láti ìbẹ̀rẹ̀, kí á tó dá ayé rárá.

24 Kí ibú omi tó wà ni mo ti wà, nígbà tí kò tíì sí àwọn orísun omi.

25 Kí á tó dá àwọn òkè ńlá sí ààyè wọn, kí àwọn òkè kéékèèké tó wà, ni mo ti wà.

26 Kí Ọlọrun tó dá ayé, ati pápá oko, kí ó tó dá erùpẹ̀ ilẹ̀.

27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó dá ojú ọ̀run sí ààyè rẹ̀, tí ó ṣe àmì bìrìkìtì sórí ibú, ní ibi tí ó dàbí ẹni pé ilẹ̀ ati ọ̀run ti pàdé,

28 nígbà tí ó ṣe awọsanma lọ́jọ̀, tí ó fi ìpìlẹ̀ orísun omi sọ ilẹ̀,

29 nígbà tí ó pààlà sí ibi tí òkun gbọdọ̀ kọjá, kí omi má baà kọjá ààyè rẹ̀. Nígbà tí ó sàmì sí ibi tí ìpìlẹ̀ ayé wà,

30 èmi ni oníṣẹ́ ọnà tí mo wà lọ́dọ̀ rẹ̀, Inú mi a máa dùn lojoojumọ, èmi a sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀ nígbà gbogbo.

31 Mo láyọ̀ ninu ayé tí àwọn ẹ̀dá alààyè ń gbé, inú mi sì ń dùn sí àwọn ọmọ eniyan.

32 “Nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ fetí sí mi, ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà mi.

33 Ẹ gbọ́ ìtọ́ni, kí ẹ sì kọ́gbọ́n, ẹ má sì ṣe àìnáání rẹ̀.

34 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbọ́ tèmi, tí ó ń ṣọ́nà lojoojumọ ní ẹnu ọ̀nà àgbàlá mi, tí ó dúró sí ẹnu ọ̀nà ilé mi.

35 Ẹni tí ó rí mi, rí ìyè, ó sì rí ojurere lọ́dọ̀ OLUWA,

36 ṣugbọn ẹni tí kò bá rí mi, ó pa ara rẹ̀ lára, gbogbo àwọn tí wọ́n kórìíra mi, ikú ni wọ́n fẹ́ràn.”

9

1 Ọgbọ́n ti kọ́lé, ó ti gbé àwọn òpó rẹ̀ mejeeje nàró.

2 Ó ti pa ẹran rẹ̀, ó ti pọn ọtí waini rẹ̀, ó sì ti tẹ́ tabili rẹ̀ kalẹ̀.

3 Ó ti rán àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀ kí wọn lọ máa kígbe lórí àwọn òkè láàrin ìlú pé:

4 “Ẹ yà síbí ẹ̀yin òpè!” Ó sọ fún ẹni tí kò lọ́gbọ́n pé,

5 “Máa bọ̀, wá jẹ lára oúnjẹ mi, kí o sì mu ninu ọtí waini tí mo ti pò.

6 Fi àìmọ̀kan sílẹ̀, kí o sì yè, kí o máa rin ọ̀nà làákàyè.”

7 Ẹni tí ń tọ́ oníyẹ̀yẹ́ eniyan sọ́nà fẹ́ kan àbùkù, ẹni tí ń bá ìkà eniyan wí ń wá ìfarapa fún ara rẹ̀.

8 Má ṣe bá oníyẹ̀yẹ́ eniyan wí, kí ó má baà kórìíra rẹ, bá ọlọ́gbọ́n wí, yóo sì fẹ́ràn rẹ.

9 Kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo tún gbọ́n sí i, kọ́ olódodo, yóo sì tún ní ìmọ̀ kún ìmọ̀.

10 Ìbẹ̀rù OLUWA ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ Ẹni Mímọ́ sì ni làákàyè.

11 Nípasẹ̀ mi ẹ̀mí rẹ yóo gùn. Ọpọlọpọ ọdún ni o óo sì lò lórí ilẹ̀ alààyè.

12 Bí o bá gbọ́n, o óo jèrè ọgbọ́n rẹ, Bí o bá sì jẹ́ pẹ̀gànpẹ̀gàn, ìwọ nìkan ni o óo jèrè rẹ̀.

13 Aláriwo ni obinrin tí kò gbọ́n, oníwọ̀ra ni, kò sì ní ìtìjú.

14 Á máa jókòó lẹ́nu ọ̀nà ilé rẹ̀, á jókòó ní ibi tí ó ga láàrin ìlú.

15 A máa kígbe pe àwọn tí ń kọjá lọ, àwọn tí ń bá tiwọn lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọn, pé,

16 “Ẹni tí ó bá jẹ́ aláìmọ̀kan, kí ó máa bọ̀!” Ó sì wí fún àwọn òmùgọ̀ pé,

17 “Omi tí eniyan bá jí mu a máa dùn, oúnjẹ tí a bá jí jẹ, oyinmọmọ ni.”

18 Àwọn tí wọ́n bá yà sọ́dọ̀ rẹ̀ kò ní mọ̀ pé ikú wà ní ilé rẹ̀, ati pé inú isà òkú ni àwọn tí wọ́n bá wọ ilé rẹ̀ wọ̀.

10

1 Àwọn òwe Solomoni nìwọ̀nyí: Ọlọ́gbọ́n ọmọ á máa mú kí inú baba rẹ̀ dùn, ṣugbọn òmùgọ̀ ọmọ a máa kó ìbànújẹ́ bá ìyá rẹ̀.

2 Ọrọ̀ tí a kójọ lọ́nà èrú kò lérè, ṣugbọn òdodo a máa gba eniyan lọ́wọ́ ikú.

3 OLUWA kì í jẹ́ kí ebi pa olódodo, ṣugbọn ó máa ń da ìfẹ́ ọkàn eniyan burúkú rú.

4 Ìmẹ́lẹ́ máa ń fa òṣì, ṣugbọn ẹni tí ó bá tẹpá mọ́ṣẹ́ yóo di ọlọ́rọ̀.

5 Ọlọ́gbọ́n ní ọmọ tí ó kórè ní àkókò ìkórè, ṣugbọn ọmọ tí ó bá ń sùn lákòókò ìkórè a máa kó ìtìjú báni.

6 Ibukun wà lórí olódodo, ṣugbọn eniyan burúkú a máa fi ìwà ìkà sinu, a sì máa sọ̀rọ̀ rere jáde lẹ́nu.

7 Ayọ̀ ni ìrántí olódodo, ṣugbọn orúkọ eniyan burúkú yóo di ohun ìgbàgbé.

8 Ọlọ́gbọ́n a máa pa òfin mọ́, ṣugbọn òmùgọ̀ onísọkúsọ yóo di ẹni ìparun.

9 Ẹni tí ó bá jẹ́ olóòótọ́ eniyan, yóo máa rìn láìfòyà, ṣugbọn àṣírí alágàbàgebè yóo tú.

10 Ẹni tí bá ń ṣẹ́jú sí ni láti sọ̀rọ̀ èké, a máa dá ìjàngbọ̀n sílẹ̀, ṣugbọn ẹni tí bá ń báni wí ní gbangba, ń wá alaafia.

11 Ẹnu olódodo dàbí orísun omi ìyè, ṣugbọn eniyan burúkú a máa fi ìwà ìkà sinu, a sì máa sọ̀rọ̀ rere jáde lẹ́nu.

12 Ìkórìíra a máa rú ìjà sókè, ṣugbọn ìfẹ́ a máa fojú fo gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ dá.

13 Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n níí máa ń jáde lẹ́nu ẹni tí ó ní òye, ṣugbọn kùmọ̀ ló yẹ ẹ̀yìn ẹni tí kò gbọ́n.

14 Ọlọ́gbọ́n eniyan a máa wá ìmọ̀ kún ìmọ̀, ṣugbọn ọ̀rọ̀ òmùgọ̀ máa ń fa ìparun mọ́ra.

15 Ohun ìní ọlọ́rọ̀ ni ààbò rẹ̀, ṣugbọn àìní talaka ni yóo pa talaka run.

16 Èrè àwọn olódodo a máa fa ìyè, ṣugbọn èrè àwọn eniyan burúkú a máa fà wọ́n sinu ẹ̀ṣẹ̀.

17 Ẹni tí ó bá gba ìtọ́ni wà ní ọ̀nà ìyè, ṣugbọn ẹni tí ó bá kọ ìbáwí yóo ṣìnà.

18 Ẹni tí ó di eniyan sinu jẹ́ ẹlẹ́tàn eniyan, ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́, òmùgọ̀ ni.

19 Bí ọ̀rọ̀ bá ti pọ̀ jù, àṣìsọ a máa wọ̀ ọ́, ṣugbọn ẹni tí ó bá kó ẹnu ara rẹ̀ ní ìjánu, ọlọ́gbọ́n ni.

20 Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo dàbí fadaka, ṣugbọn èrò ọkàn eniyan burúkú kò já mọ́ nǹkankan.

21 Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo a máa ṣe ọpọlọpọ eniyan ní anfaani, ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan a máa kú nítorí àìgbọ́n.

22 Ibukun OLUWA ní ń mú ni í là, kì í sì í fi làálàá kún un.

23 Ibi ṣíṣe a máa dùn mọ́ òmùgọ̀, ṣugbọn ìwà ọgbọ́n ni ayọ̀ fún ẹni tí ó mòye.

24 Ohun tí eniyan burúkú ń bẹ̀rù ni yóo dé bá a, ohun tí olódodo ń fẹ́ ni yóo sì rí gbà.

25 Nígbà tí ìjì líle bá ń jà, a gbá ẹni ibi lọ, ṣugbọn olódodo a fẹsẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

26 Bí ọtí kíkan ti rí sí eyín, ati bí èéfín ti rí sí ojú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ rí sí ẹni tí ó bẹ̀ ẹ́ níṣẹ́.

27 Ìbẹ̀rù OLUWA a máa mú kí ẹ̀mí eniyan gùn, ṣugbọn ìgbé ayé eniyan burúkú yóo kúrú.

28 Ìrètí olódodo yóo yọrí sí ayọ̀, ṣugbọn ìrètí ẹni ibi yóo jásí òfo.

29 OLUWA jẹ́ agbára fún àwọn tí ọ̀nà wọn tọ́, ṣugbọn ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ibi.

30 Gbọningbọnin ni olódodo yóo dúró, ṣugbọn ẹni ibi kò ní lè gbé ilẹ̀ náà.

31 Ẹnu olódodo kún fún ọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ṣugbọn ẹnu alaiṣootọ ni a pamọ́.

32 Olódodo mọ ohun tí ó dára láti sọ, ṣugbọn ti eniyan burúkú kò ju ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn lọ.

11

1 OLUWA kórìíra òṣùnwọ̀n èké, òṣùnwọ̀n tí ó péye ni inú rẹ̀ dùn sí.

2 Bí ìgbéraga bá wọlé, àbùkù a tẹ̀lé e, ṣugbọn ọgbọ́n wà pẹlu àwọn onírẹ̀lẹ̀.

3 Òtítọ́ inú àwọn olódodo a máa tọ́ wọn, ṣugbọn ìwà aiṣootọ àwọn ọ̀dàlẹ̀ níí pa wọ́n.

4 Ọrọ̀ kò jámọ́ nǹkankan ní ọjọ́ ibinu, ṣugbọn òdodo a máa gbani sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú,

5 Òdodo ẹni pípé a máa mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́, ṣugbọn ẹni ibi ṣubú nípa ìwà ìkà rẹ̀.

6 Ìwà òdodo àwọn olóòótọ́ yóo gbà wọ́n, ṣugbọn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àwọn ọ̀dàlẹ̀ yóo dè wọ́n nígbèkùn.

7 Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá kú, ìrètí wọn yóo di asán, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn tí kò mọ Ọlọrun yóo di òfo.

8 OLUWA a máa gba olódodo lọ́wọ́ ìyọnu, ṣugbọn ẹni ibi a bọ́ sinu wahala.

9 Ẹni tí kò mọ Ọlọrun a máa fi ẹnu ba ti aládùúgbò rẹ̀ jẹ́, ṣugbọn nípa ìmọ̀ a máa gba olódodo sílẹ̀.

10 Nígbà tí nǹkan bá ń dára fún olódodo, gbogbo ará ìlú a máa yọ̀, nígbà tí eniyan burúkú bá kú, gbogbo ará ìlú a sì hó ìhó ayọ̀.

11 Ìre tí olódodo bá sú fún ìlú a máa gbé orúkọ ìlú ga, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn eniyan burúkú a máa run ìlú.

12 Ẹni tí ó tẹmbẹlu aládùúgbò rẹ̀ kò gbọ́n, ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa pa ẹnu mọ́.

13 Olófòófó a máa tú àṣírí, ṣugbọn ẹni tí ó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a máa pa àṣírí mọ́.

14 Níbi tí kò bá ti sí ìtọ́ni, orílẹ̀-èdè a máa ṣubú, ṣugbọn ẹni tí ó bá ní ọpọlọpọ olùdámọ̀ràn yóo máa gbé ní àìléwu.

15 Ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò yóo rí ìyọnu, ṣugbọn ẹni tí ó bá kọ̀ tí kò ṣe onídùúró yóo wà láìléwu.

16 Obinrin onínúrere gbayì, ṣugbọn ọrọ̀ nìkan ni ìkà yóo ní.

17 Ẹni tí ó ṣoore ṣe é fún ara rẹ̀, ẹni tí ó sì ń ṣìkà ó ń ṣe é fún ara rẹ̀.

18 Owó ọ̀yà èké ni eniyan burúkú óo gbà, ṣugbọn ẹni tí ó bá hùwà òdodo yóo gba èrè òtítọ́.

19 Ẹni tí ó dúró ṣinṣin lórí òdodo yóo yè, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń lépa ibi yóo kú.

20 Ẹni ìríra ni àwọn alágàbàgebè lójú OLUWA, ṣugbọn àwọn tí ọ̀nà wọn mọ́ ni ìdùnnú fún un.

21 Dájúdájú ẹni ibi kò ní lọ láìjìyà, ṣugbọn a óo gba àwọn olódodo là.

22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ ni obinrin tí ó lẹ́wà tí kò ní làákàyè.

23 Ìfẹ́ ọkàn olódodo a máa yọrí sí rere, ṣugbọn ìrètí eniyan burúkú a máa já sí ibinu.

24 Ẹnìkan wà tíí máa ṣe ìtọrẹ àánú káàkiri, sibẹsibẹ àníkún ni ó ń ní, ẹnìkan sì wà tí ó háwọ́, sibẹsibẹ aláìní ni.

25 Ẹni tí ó bá lawọ́ yóo máa ní àníkún, ẹni tí ó bá jẹ́ kí ọkàn ẹlòmíràn balẹ̀, ọkàn tirẹ̀ náà yóo balẹ̀.

26 Ẹni tí ó bá ń kó oúnjẹ pamọ́, yóo gba ègún sórí, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń ta oúnjẹ, yóo rí ibukun gbà.

27 Ẹni tí ó bá ń wá ire, yóo rí ojurere, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń wá ibi, ibi yóo bá a.

28 Ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóo rẹ̀ dànù bí òdòdó, ṣugbọn olódodo yóo rú bí ewé tútù.

29 Ẹni tí ó bá mú ìyọnu dé bá ìdílé rẹ̀ yóo jogún òfo, òmùgọ̀ ni yóo sì máa ṣe iranṣẹ ọlọ́gbọ́n.

30 Èso olódodo ni igi ìyè, ṣugbọn ìwà aibikita fún òfin a máa paniyan.

31 Bí a óo bá san ẹ̀san fún olódodo láyé, mélòó-mélòó ni ti eniyan burúkú ati ẹlẹ́ṣẹ̀.

12

1 Ẹni tí ó fẹ́ ìtọ́sọ́nà, ó fẹ́ ìmọ̀, ṣugbọn ẹni tí ó kórìíra ìbáwí òmùgọ̀ ni.

2 Eniyan rere a máa ní ojurere lọ́dọ̀ OLUWA, ṣugbọn ẹni tí ń pète ìkà ni yóo dá lẹ́bi.

3 Kò sí ẹni tí ó lè ti ipa ìwà ìkà fi ìdí múlẹ̀, ṣugbọn gbòǹgbò olódodo kò ní fà tu.

4 Obinrin oníwàrere ni adé orí ọkọ rẹ̀, ṣugbọn obinrin tí ń dójúti ọkọ dàbí ọyún inú egungun.

5 Èrò ọkàn olódodo dára, ṣugbọn ẹ̀tàn ni ìmọ̀ràn àwọn eniyan burúkú.

6 Ọ̀rọ̀ àwọn eniyan burúkú dàbí ẹni tí ó lúgọ láti pa eniyan, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo a máa gbani là.

7 A bi àwọn eniyan burúkú lulẹ̀, wọ́n sì parun, ṣugbọn ìdílé olódodo yóo dúró gbọningbọnin.

8 À máa ń yin eniyan gẹ́gẹ́ bí ó bá ṣe gbọ́n tó, ṣugbọn ọlọ́kàn àgàbàgebè yóo di ẹni ẹ̀gàn.

9 Mẹ̀kúnnù tí ó ní iṣẹ́, tí ó tún gba ọmọ-ọ̀dọ̀ ó sàn ju ẹni tí ó ń ṣe bí eniyan pataki, ṣugbọn tí kò rí oúnjẹ jẹ lọ.

10 Olódodo a máa ka ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn rẹ̀ sí, ṣugbọn eniyan burúkú rorò sí tirẹ̀.

11 Ẹni tí ó bá ń dáko yóo ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń lo àkókò rẹ̀ lórí ohun tí kò lérè, kò lọ́gbọ́n lórí.

12 Ilé ìṣọ́ àwọn eniyan burúkú yóo di òkítì àlàpà, ṣugbọn gbòǹgbò eniyan rere a máa fìdí múlẹ̀ sí i.

13 Ọ̀rọ̀ ẹnu eniyan burúkú a máa mú un bíi tàkúté, ṣugbọn olódodo a máa bọ́ ninu ìyọnu.

14 Ọ̀rọ̀ ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa mú ìtẹ́lọ́rùn bá a, a sì máa jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

15 Ọ̀nà òmùgọ̀ níí dára lójú tirẹ̀, ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa fetí sí ìmọ̀ràn.

16 Bí inú bá ń bí òmùgọ̀, kíá ni gbogbo eniyan yóo mọ̀, ṣugbọn ọlọ́gbọ́n kìí ka ọ̀rọ̀ àbùkù sí.

17 Ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ a máa jẹ́rìí òdodo, ṣugbọn irọ́ ni ẹlẹ́rìí èké máa ń pa.

18 Ẹni tí í bá máa ń sọ̀rọ̀ jàbùjàbù láìronú, ọ̀rọ̀ rẹ̀ dàbí kí á fi idà gún eniyan, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹni wo ọgbẹ́ sàn.

19 Ọ̀rọ̀ òtítọ́ yóo máa wà títí ayé ṣugbọn irọ́, fún ìgbà díẹ̀ ni.

20 Ẹ̀tàn ń bẹ lọ́kàn àwọn tí ń pète ibi, ṣugbọn àwọn tí ń gbèrò rere ní ayọ̀.

21 Nǹkan burúkú kò ní ṣẹlẹ̀ sí olódodo, ṣugbọn eniyan burúkú yóo kún fún ìyọnu.

22 OLUWA kórìíra ẹni tí ń parọ́, ṣugbọn inú rẹ̀ dùn sí olóòótọ́.

23 Ọlọ́gbọ́n a máa fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́, ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ a máa kéde agọ̀ wọn.

24 Ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ ni yóo máa jẹ́ olórí, ṣugbọn ọ̀lẹ ni a óo máa mú ṣiṣẹ́ tipátipá.

25 Ọ̀pọ̀ ìpayà máa ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá eniyan, ṣugbọn ọ̀rọ̀ rere a máa mú inú eniyan dùn.

26 Olódodo a máa yipada kúrò ninu ibi, ṣugbọn ìwà ẹni ibi a máa mú un ṣìnà.

27 Ọwọ́ ọ̀lẹ kò lè tẹ ohun tí ó ń lé, ṣugbọn ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

28 Ní ọ̀nà òdodo ni ìyè wà, kò sí ikú ní ojú ọ̀nà rẹ̀.

13

1 Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀, ṣugbọn ẹlẹ́yà kì í gbọ́ ìbáwí.

2 Eniyan rere a máa rí ire nítorí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀, ṣugbọn ohun tí àwọn ẹlẹ́tàn ń fẹ́ ni ìwà jàgídíjàgan.

3 Ẹni tí ó ń ṣọ́ ẹnu rẹ̀, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó ń ṣọ́, ẹni tí ń sọ̀rọ̀ àsọjù yóo parun.

4 Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́ nǹkan, ṣugbọn kò ní rí i, ṣugbọn ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ yóo ní ọpọlọpọ nǹkan.

5 Olóòótọ́ a máa kórìíra èké, ṣugbọn eniyan burúkú a máa hùwà ìtìjú ati àbùkù.

6 Òdodo a máa dáàbò bo ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ bá tọ́, ṣugbọn ẹ̀ṣẹ̀ a máa bi eniyan burúkú ṣubú.

7 Ẹnìkan ń ṣe bí ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ kò ní nǹkankan, níbẹ̀ ni ẹlòmíràn ń ṣe bíi talaka, ṣugbọn tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

8 Ọlọ́rọ̀ a máa fi ohun ìní rẹ̀ ra ẹ̀mí rẹ̀ pada, ṣugbọn talaka kì í tilẹ̀ gbọ́ ìbáwí.

9 Ìmọ́lẹ̀ olódodo a máa fi ayọ̀ tàn, ṣugbọn fìtílà eniyan burúkú yóo kú.

10 Ìjà ni ìgbéraga máa ń fà, ṣugbọn àwọn tí wọ́n bá gba ìmọ̀ràn yóo ní ọgbọ́n.

11 Ọrọ̀ tí a fi ìkánjú kójọ kì í pẹ́ dínkù, ṣugbọn ẹni tí ó bá fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ kó ọrọ̀ jọ yóo máa ní àníkún.

12 Bí ìrètí bá pẹ́ jù, a máa kó àárẹ̀ bá ọkàn, ṣugbọn kí á tètè rí ohun tí à ń fẹ́ a máa mú ara yá gágá.

13 Ẹni tí ó kẹ́gàn ìmọ̀ràn yóo parun, ṣugbọn ẹni tí ó bá bẹ̀rù òfin yóo jèrè rẹ̀.

14 Ìtọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè a máa yọni ninu tàkúté ikú.

15 Ẹni tí ó ní òye yóo rí ojurere, ṣugbọn ọ̀nà àwọn tí kò ṣe é gbẹ́kẹ̀lé ni ìparun wọn.

16 Olóye eniyan a máa fi ìmọ̀ ṣe ohun gbogbo, ṣugbọn òmùgọ̀ a máa fi agọ̀ rẹ̀ yangàn.

17 Iranṣẹ burúkú a máa kó àwọn eniyan sinu wahala, ṣugbọn ikọ̀ tí ó bá jẹ́ olóòótọ́ a máa mú ìrẹ́pọ̀ wá.

18 Òṣì ati àbùkù ni yóo bá ẹni tí ó kọ ìmọ̀ràn, ṣugbọn ẹni tó bá gba ìbáwí yóo gba iyì.

19 Bí èrò ọkàn ẹni bá ṣẹ, a máa fúnni láyọ̀, ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ kórìíra ati kọ ibi sílẹ̀.

20 Bí eniyan bá ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóo gbọ́n, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń bá òmùgọ̀ kẹ́gbẹ́ yóo ṣìnà.

21 Àjálù kì í dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣugbọn olódodo yóo máa rí ire.

22 Eniyan rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀, ṣugbọn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ń kó ọrọ̀ jọ fún àwọn olóòótọ́.

23 Oko tí talaka dá lè mú ọpọlọpọ oúnjẹ jáde, ṣugbọn àwọn alaiṣootọ níí kó gbogbo rẹ̀ lọ.

24 Ẹni tí kì í bá na ọmọ rẹ̀ kò fẹ́ràn rẹ̀, ṣugbọn ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóo máa bá a wí.

25 Olódodo a máa jẹ àjẹtẹ́rùn, ṣugbọn eniyan burúkú kì í yó.

14

1 Ọlọ́gbọ́n obinrin a máa kọ́ ilé rẹ̀, ṣugbọn òmùgọ̀ a máa fi ọwọ́ ara rẹ̀ tú tirẹ̀ palẹ̀.

2 Ẹni tí ń rìn pẹlu òótọ́ inú yóo bẹ̀rù OLUWA, ṣugbọn ẹni tí ń rin ìrìn ségesège yóo kẹ́gàn rẹ̀.

3 Ọ̀rọ̀ ẹnu òmùgọ̀ dàbí pàṣán ní ẹ̀yìn ara rẹ̀, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n a máa dáàbò bò ó.

4 Níbi tí kò bá sí mààlúù tí ń tu ilẹ̀, kò lè sí oúnjẹ, ṣugbọn agbára ọpọlọpọ mààlúù níí mú ọpọlọpọ ìkórè wá.

5 Ẹlẹ́rìí òtítọ́ kì í parọ́, ṣugbọn irọ́ ṣá ni ti ẹlẹ́rìí èké.

6 Pẹ̀gànpẹ̀gàn a máa wá ọgbọ́n, sibẹ kò ní rí i, ṣugbọn ati ní ìmọ̀ kò ṣòro fún ẹni tí ó ní òye.

7 Yẹra fún òmùgọ̀, nítorí o kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n lẹ́nu rẹ̀.

8 Ohun tí ó jẹ́ ọgbọ́n fún ọlọ́gbọ́n ni pé kí ó kíyèsí ọ̀nà ara rẹ̀, ṣugbọn àìmòye àwọn òmùgọ̀ kún fún ìtànjẹ.

9 Àwọn òmùgọ̀ a máa fi ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ṣe àwàdà, ṣugbọn àwọn olódodo a máa rí ojurere.

10 Kálukú ló mọ ìbànújẹ́ ọkàn ara rẹ̀, kò sì sí àjèjì tí ń báni pín ninu ayọ̀.

11 Ìdílé ẹni ibi yóo parun, ṣugbọn ilé olódodo yóo máa gbèrú títí lae.

12 Ọ̀nà kan wà tí ó dàbí ẹni pé ó tọ́ lójú eniyan, ṣugbọn òpin rẹ̀, ikú ni.

13 Eniyan lè máa rẹ́rìn-ín, kí inú rẹ̀ má dùn, ìbànújẹ́ sì le gbẹ̀yìn ayọ̀.

14 Alágàbàgebè yóo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́, ẹni rere yóo sì jèrè ìwà rere rẹ̀.

15 Òpè eniyan a máa gba ohun gbogbo gbọ́, ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa kíyèsí ibi tí ó ń lọ.

16 Ọlọ́gbọ́n a máa ṣọ́ra, a sì máa sá fún ibi, ṣugbọn òmùgọ̀ kì í rọra ṣe, kì í sì í bìkítà.

17 Onínúfùfù a máa hùwà òmùgọ̀, ṣugbọn onílàákàyè a máa ní sùúrù.

18 Àwọn òpè a máa jogún àìgbọ́n, ṣugbọn àwọn ọlọ́gbọ́n a máa dé adé ìmọ̀.

19 Àwọn ẹni ibi yóo tẹríba fún àwọn ẹni rere, àwọn eniyan burúkú yóo sì tẹríba lẹ́nu ọ̀nà àwọn olódodo.

20 Àwọn aládùúgbò talaka pàápàá kórìíra rẹ̀, ṣugbọn ọlọ́rọ̀ a máa ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́.

21 Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò rẹ̀ dẹ́ṣẹ̀, ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fun ẹni tí ó bá ṣàánú talaka.

22 Àwọn tí wọn ń pète ibi ti ṣìnà, ṣugbọn àwọn tí wọn ń gbèrò ire yóo rí ojurere ati òtítọ́.

23 Kò sí iṣẹ́ kan tí kò lérè, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu lásán láìsí iṣẹ́, a máa sọ eniyan di aláìní.

24 Ọgbọ́n ni adé àwọn ọlọ́gbọ́n, ṣugbọn ìwà aláìgbọ́n jẹ́ yẹ̀yẹ́ àwọn òmùgọ̀.

25 Ẹlẹ́rìí tòótọ́ a máa gba ẹ̀mí là, ṣugbọn ọ̀dàlẹ̀ ni òpùrọ́.

26 Ninu ìbẹ̀rù OLUWA ni igbẹkẹle tí ó dájú wà, níbẹ̀ ni ààbò wà fún àwọn ọmọ ẹni.

27 Ìbẹ̀rù OLUWA ni orísun ìyè, òun níí mú ká yẹra fún tàkúté ikú.

28 Ọ̀pọ̀ eniyan ni ògo ọba, olórí tí kò bá ní eniyan yóo parun.

29 Ẹni tí kì í báá yára bínú lóye lọpọlọpọ, ṣugbọn onínúfùfù ń fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

30 Ìbàlẹ̀ ọkàn a máa mú kí ara dá ṣáṣá, ṣugbọn ìlara a máa dá egbò sinu eegun.

31 Ẹni tí ó bá ni talaka lára àbùkù Ẹlẹ́dàá rẹ̀ ni ó ń ta, ṣugbọn ẹni tí ó ṣàánú fún àwọn aláìní ń bu ọlá fún Ẹlẹ́dàá rẹ̀.

32 Eniyan burúkú ṣubú nítorí ìwà ibi rẹ̀, ṣugbọn olódodo rí ààbò nípasẹ̀ òtítọ́ inú rẹ̀.

33 Ọgbọ́n kún inú ẹni tí ó mòye, ṣugbọn kò sí ohun tí ó jọ ọgbọ́n lọ́kàn òmùgọ̀.

34 Òdodo ní ń gbé orílẹ̀-èdè lékè, ṣugbọn ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ ẹ̀gàn fún orílẹ̀-èdè.

35 Iranṣẹ tí ó bá hùwà ọlọ́gbọ́n a máa rí ojurere ọba, ṣugbọn inú a máa bí ọba sí iranṣẹ tí ó bá hùwà ìtìjú.

15

1 Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ a máa mú kí ibinu rọlẹ̀, ṣugbọn ọ̀rọ̀ líle níí ru ibinu sókè.

2 Lẹ́nu ọlọ́gbọ́n ni ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ti ń jáde, ṣugbọn òmùgọ̀ a máa sọ̀rọ̀ agọ̀.

3 Ojú OLUWA wà níbi gbogbo, ó ń ṣọ́ àwọn eniyan burúkú ati àwọn eniyan rere.

4 Ọ̀rọ̀ tí a fi pẹ̀lẹ́ sọ dàbí igi ìyè, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn a máa bani lọ́kàn jẹ́.

5 Òmùgọ̀ ọmọ á kẹ́gàn ìtọ́sọ́nà baba rẹ̀, ṣugbọn ọmọ tí ó gbọ́ ìkìlọ̀, ọlọ́gbọ́n ni.

6 Ilé olódodo kún fún ọpọlọpọ ìṣúra, ṣugbọn kìkì ìdààmú ni àkójọ èrè eniyan burúkú.

7 Ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa tan ìmọ̀ kálẹ̀, ṣugbọn ti òmùgọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀.

8 Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú lójú OLUWA, ṣugbọn adura olódodo jẹ́ ìdùnnú rẹ̀.

9 OLUWA kórìíra ìwà àwọn eniyan burúkú, ṣugbọn ó fẹ́ràn àwọn tí ń hùwà òdodo.

10 Ìbáwí pupọ ń bẹ fún ẹni tí ó yapa kúrò ní ọ̀nà rere, ẹni tí ó bá kórìíra ìbáwí yóo kú.

11 Isà òkú ati ìparun kò pamọ́ lójú OLUWA, mélòó-mélòó ni ọkàn eniyan.

12 Inú pẹ̀gànpẹ̀gàn kì í dùn sí ìbáwí, kì í bèèrè ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ọlọ́gbọ́n.

13 Inú dídùn a máa múni dárayá, ṣugbọn ìbànújẹ́ a máa mú kí ojú eniyan rẹ̀wẹ̀sì.

14 Ẹni tí ó ní òye a máa wá ìmọ̀, ṣugbọn agọ̀ ni oúnjẹ òmùgọ̀.

15 Gbogbo ọjọ́ ayé ẹni tí a ni lára kún fún ìpọ́njú, ṣugbọn ojoojumọ ni ọdún fún ẹni tí inú rẹ̀ dùn.

16 Ó sàn kí á jẹ́ talaka, kí á sì ní ìbẹ̀rù OLUWA, ju kí á jẹ́ ọlọ́rọ̀, kí á sì kún fún ìyọnu lọ.

17 Ọbẹ̀ ẹ̀fọ́ pẹlu ìfẹ́, sàn ju ẹran mààlúù tòun ti ìkórìíra lọ.

18 Onínúfùfù a máa rú ìjà sókè, ṣugbọn onínútútù a máa pẹ̀tù sí ibinu.

19 Ẹ̀gún kún bo ọ̀nà ọ̀lẹ, ṣugbọn ọ̀nà olódodo dàbí òpópó tí ń dán.

20 Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣugbọn òmùgọ̀ ọmọ níí kẹ́gàn ìyá rẹ̀.

21 Ayọ̀ ni ìwà òmùgọ̀ jẹ́ fún aláìgbọ́n, ṣugbọn ẹni tí ó ní òye a máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́.

22 Àìsí ìmọ̀ràn a máa mú kí ètò dàrú, ṣugbọn ọpọlọpọ ìmọ̀ràn a máa mú kí ó yọrí sí rere.

23 Ìdáhùn kíkún a máa fúnni láyọ̀, kí ọ̀rọ̀ bọ́ sí àsìkò dára lọpọlọpọ!

24 Ọ̀nà ọlọ́gbọ́n lọ tààrà sinu ìyè, kí ó má baà bọ́ sinu isà òkú.

25 OLUWA a máa wó ilé agbéraga, ṣugbọn ó ṣe àmójútó ààlà opó.

26 Ohun ìríra ni èrò ọkàn ẹni ibi lójú OLUWA, ṣugbọn ọrọ̀ àwọn ẹni mímọ́ jẹ́ dídùn inú rẹ̀.

27 Àwọn tí ń ṣojúkòkòrò èrè àìtọ́ ń kó ìyọnu bá ilé wọn, ṣugbọn àwọn tí wọn kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóo yè.

28 Olódodo a máa ronú kí ó tó fèsì ọ̀rọ̀, ṣugbọn ọ̀rọ̀ burúkú níí máa jáde lẹ́nu àwọn eniyan burúkú.

29 OLUWA jìnnà sí eniyan burúkú, ṣugbọn a máa gbọ́ adura olódodo.

30 Ọ̀yàyà a máa mú inú dùn, ìròyìn ayọ̀ a sì máa mú ara yá.

31 Ẹni tó gbọ́ ìbáwí rere yóo wà láàrin àwọn ọlọ́gbọ́n.

32 Ẹni tí kò náání ìbáwí tàbùkù ara rẹ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá gba ìmọ̀ràn yóo ní òye.

33 Ìbẹ̀rù OLUWA níí kọ́ni lọ́gbọ́n, ìwà ìrẹ̀lẹ̀ níí ṣáájú iyì.

16

1 Èrò ọkàn ni ti eniyan ṣugbọn OLUWA ló ni ìdáhùn.

2 Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó mọ́ lójú ara rẹ̀, ṣugbọn OLUWA ló rí ọkàn.

3 Fi gbogbo àdáwọ́lé rẹ lé OLUWA lọ́wọ́, èrò ọkàn rẹ yóo sì yọrí sí rere.

4 OLUWA a máa jẹ́ kí ohun gbogbo yọrí sí bí ó bá ti fẹ́, ó dá eniyan burúkú fún ọjọ́ ìyọnu.

5 OLUWA kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ agbéraga, dájúdájú kò ní lọ láìjìyà.

6 Àánú ati òtítọ́ a máa ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀, ìbẹ̀rù OLUWA a sì máa mú ibi kúrò.

7 Bí ọ̀nà eniyan bá tẹ́ OLUWA lọ́rùn, a máa mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ pàápàá bá a gbé pẹlu alaafia.

8 Ìwọ̀nba ọrọ̀ pẹlu òdodo, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ tí a kójọ lọ́nà èrú lọ.

9 Eniyan lè jókòó kí ó ṣètò ìgbésẹ̀ rẹ̀, ṣugbọn OLUWA níí tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni.

10 Pẹlu ìmísí Ọlọrun ni ọba fi ń sọ̀rọ̀, ìdájọ́ aiṣododo kò gbọdọ̀ ti ẹnu rẹ̀ jáde.

11 Ti OLUWA ni òṣùnwọ̀n pípé, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo ohun tí à ń wọ̀n.

12 Àwọn ọba kórìíra ibi ṣíṣe, nítorí nípa òdodo ni a fìdí ìjọba múlẹ̀.

13 Inú ọba a máa dùn sí olódodo, ọba sì máa ń fẹ́ràn àwọn tí ń sọ òtítọ́.

14 Iranṣẹ ikú ni ibinu ọba, ọlọ́gbọ́n eniyan níí tù ú lójú.

15 Ìyè wà ninu ojurere ọba, ojurere rẹ̀ sì dàbí ṣíṣú òjò ní àkókò òjò àkọ́rọ̀.

16 Ó sàn kí eniyan ní òye ju kí ó ní wúrà lọ, ó sì sàn kí eniyan yan ìmọ̀ ju kí ó yan fadaka lọ.

17 Olóòótọ́ kì í tọ ọ̀nà ibi, ẹni tí ń ṣọ́ra, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó ń pamọ́.

18 Ìgbéraga ní ń ṣáájú ìparun, agídí ní ń ṣáájú ìṣubú.

19 Ó sàn kí eniyan jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ pẹlu àwọn talaka ju kí ó bá agbéraga pín ìkógun lọ.

20 Yóo dára fún ẹni tí ó bá ń gbọ́ràn, ẹni tí ó bá sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ní ayọ̀.

21 Àwọn tí wọ́n gbọ́n ni à ń pè ní amòye, ọ̀rọ̀ tí ó tuni lára a máa yíni lọ́kàn pada.

22 Orísun ìyè ni ọgbọ́n jẹ́ fún àwọn tí wọn ní i, agọ̀ sì jẹ́ ìjìyà fún àwọn òmùgọ̀.

23 Ọgbọ́n inú níí mú kí ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n tọ̀nà, ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ a sì máa yíni lọ́kàn pada.

24 Ọ̀rọ̀ tí ó tuni lára dàbí afárá oyin, a máa mú inú ẹni dùn, a sì máa mú ara ẹni yá.

25 Ọ̀nà kan wà tí ó tọ́ lójú eniyan, ṣugbọn òpin rẹ̀, ikú ni.

26 Ebi níí mú kí òṣìṣẹ́ múra síṣẹ́, ohun tí a óo jẹ ní ń lé ni kiri.

27 Eniyan lásán a máa pète ibi, ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ dàbí iná tí ń jóni.

28 Ṣòkèṣodò a máa dá ìjà sílẹ̀, ọ̀rọ̀ àhesọ a máa tú ọ̀rẹ́ kòríkòsùn.

29 Ìkà eniyan tan aládùúgbò rẹ̀, ó darí rẹ̀ lọ sọ́nà tí kò tọ́.

30 Ẹni tí ó bá ń ṣẹ́jú sí ni, ète ibi ló fẹ́ pa, ẹni tí ó bá ń fúnnu pọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ burúkú ni yóo sọ jáde.

31 Adé ògo ni ewú orí, nípa ìgbé ayé òdodo ni a fi lè ní i.

32 Ẹni tí kì í tètè bínú sàn ju alágbára lọ, ẹni tí ń kó ara rẹ̀ níjàánu sàn ju ẹni tí ó jagun gba odidi ìlú lọ.

33 À máa ṣẹ́ gègé kí á lè mọ ìdí ọ̀ràn, ṣugbọn OLUWA nìkan ló lè pinnu ohunkohun.

17

1 Kí á fi alaafia jẹun, láìsí ọbẹ̀, ó sàn ju kí á máa fi ẹran jẹun pẹlu ìyọnu lọ.

2 Ẹrú tí ó bá mọ ìwà hù, yóo di ọ̀gá lórí ọmọ tí ń hùwà ìbàjẹ́, yóo sì jókòó pín ninu ogún bí ẹni pé ọ̀kan ninu àwọn ọmọ ni.

3 Iná ni a fi ń dán fadaka ati wúrà wò, ṣugbọn OLUWA ní ń dán ọkàn wò.

4 Aṣebi a máa tẹ́tí sí ẹni ibi, òpùrọ́ a sì máa fetí sílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ ìkà.

5 Ẹni tí ń fi talaka ṣẹ̀sín, ẹlẹ́dàá talaka ní ń tàbùkù, ẹni tí inú rẹ̀ dùn sí wahala ẹni ẹlẹ́ni kò ní lọ láìjìyà.

6 Ọmọ ọmọ ni adé arúgbó, òbí sì ni ògo àwọn ọmọ.

7 Ọ̀rọ̀ rere ṣe àjèjì sí ẹnu òmùgọ̀, bẹ́ẹ̀ ni irọ́ pípa kò yẹ àwọn olórí.

8 Àbẹ̀tẹ́lẹ̀ dàbí òògùn ajẹ́-bí-idán lójú ẹni tí ń fúnni, ibi gbogbo tí olúwarẹ̀ bá lọ ni ó ti ń ṣe àṣeyege.

9 Ẹni tí ń dárí ji ni ń wá ìfẹ́, ẹni tí ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ a máa ya ọ̀rẹ́ nípá.

10 Ìbáwí a máa dun ọlọ́gbọ́n ju kí wọ́n nà òmùgọ̀ ní ọgọrun-un pàṣán lọ.

11 Ọ̀tẹ̀ ṣá ni ti eniyan burúkú ní gbogbo ìgbà, ìkà òjíṣẹ́ ni a óo sì rán sí i.

12 Ó sàn kí eniyan pàdé ẹranko beari tí a kó lọ́mọ, ju kí ó pàdé òmùgọ̀ ninu agọ̀ rẹ̀ lọ.

13 Ẹni tí ó fibi san oore, ibi kò ní kúrò ninu ilé rẹ̀ lae.

14 Ìbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí kí eniyan ya odò tí wọn sé, dá a dúró kí ó tó di ńlá.

15 Ẹni tí ń gbé àre fún ẹlẹ́bi ati ẹni tí ń gbé ẹ̀bi fún aláre, OLUWA kórìíra ekinni-keji wọn.

16 Owó kò wúlò lọ́wọ́ òmùgọ̀ pé kí ó fi ra ọgbọ́n, nígbà tí kò ní òye?

17 Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo, ṣugbọn a bí arakunrin láti dúró tini ní ìgbà ìpọ́njú.

18 Ẹni tí kò bá gbọ́n níí jẹ́jẹ̀ẹ́, láti ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.

19 Ẹni tí ó bá fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀, ẹni tí ó bá fẹ́ràn kí á máa fi owó ṣe àṣehàn ń wá ìparun.

20 Ẹni tí ó ní ọkàn ẹ̀tàn kò ní ṣe àṣeyege, ẹlẹ́nu meji yóo bọ́ sinu ìyọnu.

21 Ìbànújẹ́ ni kí eniyan bí ọmọ tí kò gbọ́n, kò sí ayọ̀ fún baba òmùgọ̀.

22 Ọ̀yàyà jẹ́ òògùn tí ó dára fún ara, ṣugbọn ìbànújẹ́ a máa mú kí eniyan rù.

23 Eniyan burúkú a máa gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ níkọ̀kọ̀, láti yí ìdájọ́ po.

24 Ẹni tí ó ní òye a máa tẹjúmọ́ ọgbọ́n, ṣugbọn ojú òmùgọ̀ kò gbé ibìkan, ó ń wo òpin ilẹ̀ ayé.

25 Òmùgọ̀ ọmọ jẹ́ ìbànújẹ́ baba rẹ̀, ati ọgbẹ́ ọkàn fún ìyá tí ó bí i.

26 Kò tọ̀nà láti fi ipá mú aláìṣẹ̀ san owó ìtanràn, nǹkan burúkú ni kí á na gbajúmọ̀ tí kò rú òfin.

27 Ẹni tí ó bá ní ìmọ̀ a máa kó ahọ́n rẹ̀ ní ìjánu, ẹni tí ó bá jẹ́ olóye eniyan a máa ṣe jẹ́ẹ́.

28 A máa ka òmùgọ̀ pàápàá kún ọlọ́gbọ́n, bí ó bá pa ẹnu rẹ̀ mọ́, olóye ni àwọn eniyan yóo pè é, bí ó bá panu mọ́ tí kò sọ̀rọ̀.

18

1 Onímọ-tara-ẹni-nìkan ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀, láti tako ìdájọ́ òtítọ́.

2 Òmùgọ̀ kò ní inú dídùn sí ìmọ̀, àfi kí ó ṣá máa sọ èrò ọkàn rẹ̀.

3 Nígbà tí ìwà burúkú bá dé, ẹ̀gàn yóo dé, bí àbùkù bá wọlé ìtìjú yóo tẹ̀lé e.

4 Ọ̀rọ̀ ẹnu eniyan dàbí odò jíjìn, orísun ọgbọ́n dàbí omi odò tí ń tú jáde.

5 Kò dára kí á ṣe ojuṣaaju sí eniyan burúkú, tabi kí á dá olódodo ní ẹjọ́ ẹ̀bi.

6 Ẹnu òmùgọ̀ a máa dá ìjà sílẹ̀, ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ a sì máa bá a wá pàṣán.

7 Ẹnu òmùgọ̀ ni yóo tì í sinu ìparun, ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ni yóo sì ṣe tàkúté mú un.

8 Ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ olófòófó dàbí òkèlè oúnjẹ dídùn, a máa wọni lára ṣinṣin.

9 Ẹni tí ń ṣe ìmẹ́lẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀, ẹgbẹ́ ni òun ati ẹni tí ń ba nǹkan jẹ́.

10 Orúkọ OLUWA jẹ́ ilé-ìṣọ́ tí ó lágbára, olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì yè.

11 Ohun ìní ọlọ́rọ̀ ni ìlú olódi wọn, lójú wọn, ó dàbí odi ńlá tí ń dáàbò bò wọ́n.

12 Ìgbéraga níí ṣáájú ìparun, ìrẹ̀lẹ̀ níí ṣáájú iyì.

13 Ìwà òmùgọ̀ ni, ìtìjú sì ni, kí eniyan fèsì sí ọ̀rọ̀ kí ó tó gbọ́ ìdí rẹ̀.

14 Eniyan lè farada àìsàn, ṣugbọn ta ló lè farada ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn?

15 Ọkàn ọlọ́gbọ́n a máa fẹ́ ìmọ̀, etí ni ọlọ́gbọ́n fi wá a kiri.

16 Ẹ̀bùn a máa ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ẹni tí ń fúnni lẹ́bùn, a sì mú un dé iwájú ẹni gíga.

17 Ẹni tí ó bá kọ́kọ́ rojọ́ níí dàbí ẹni tí ó jàre, títí tí ẹnìkejì yóo fi bi í ní ìbéèrè,

18 Gègé ṣíṣẹ́ a máa yanjú ọ̀rọ̀ a sì parí gbolohun asọ̀ láàrin àwọn alágbára.

19 Ọkàn arakunrin tí eniyan bá ṣẹ̀ a máa le bí ìlú olódi, àríyànjiyàn sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ilé ìṣọ́.

20 Eniyan lè fi ọ̀rọ̀ ẹnu wá oúnjẹ fún ara rẹ̀, a lè jẹ oúnjẹ tí a bá fi ọ̀rọ̀ ẹnu wá ní àjẹyó ati àjẹṣẹ́kù.

21 Ahọ́n lágbára láti pani ati láti lani, ẹni tí ó bá fẹ́ràn rẹ̀ yóo jèrè rẹ̀.

22 Ẹni tí ó bá rí aya fẹ́ rí ohun rere, ó sì rí ojurere lọ́dọ̀ OLUWA.

23 Ẹ̀bẹ̀ ni talaka bẹ̀, ṣugbọn ọlọ́rọ̀ á dáhùn tìkanra-tìkanra.

24 Àwọn ọ̀rẹ́ kan wà, ọ̀rẹ́ àfẹnujẹ́ ni wọ́n, ṣugbọn ọ̀rẹ́ mìíràn wà tí ó fi ara mọ́ni ju ọmọ ìyá ẹni lọ.

19

1 Talaka tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú, ó sàn ju òmùgọ̀ eniyan, tí ó ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn lọ.

2 Kò dára kí eniyan wà láìní ìmọ̀, ẹni bá ń kánjú rìn jù a máa ṣìnà.

3 Nígbà tí ìwà òmùgọ̀ bá kó ìparun bá a, ọkàn rẹ̀ a máa bá OLUWA bínú.

4 Ọrọ̀ a máa mú kí eniyan ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́ titun, ṣugbọn àwọn ọ̀rẹ́ talaka a máa kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

5 Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, bẹ́ẹ̀ ni òpùrọ́ kò ní bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀san ibi.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan níí máa ń wá ojurere ẹni tó lawọ́, gbogbo eniyan sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ń fúnni lẹ́bùn.

7 Gbogbo àwọn arakunrin talaka ni wọ́n kórìíra rẹ̀, kí á má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí wọ́n jìnnà sí i! Ó fọ̀rọ̀ ẹnu fà wọ́n títí, sibẹ wọn kò súnmọ́ ọn.

8 Ẹni tí ó ní ọgbọ́n fẹ́ràn ara rẹ̀, ẹni tí ó bá sì ní òye, yóo ṣe rere.

9 Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, ẹni tí ó ń pa irọ́ yóo parun.

10 Ìgbádùn kò yẹ òmùgọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ kí ẹrú jọba lórí àwọn ìjòyè.

11 Ọgbọ́n kì í jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yára bínú, ògo rẹ̀ sì níláti fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ dá.

12 Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun, ṣugbọn ojurere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko tútù.

13 Òmùgọ̀ ọmọ lè kó ìparun bá baba rẹ̀, iyawo oníjà dàbí omi òjò tí ń kán tó, tó, tó, láì dáwọ́ dúró.

14 A máa ń jogún ilé ati ọrọ̀ lọ́wọ́ baba ẹni, ṣugbọn OLUWA níí fúnni ní aya rere.

15 Ìwà ọ̀lẹ a máa múni sùn fọnfọn, ebi níí sìí pa alápá-má-ṣiṣẹ́.

16 Ẹni tí ó bá pa òfin mọ́, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó pamọ́, ẹni tí ó kọ ọ̀nà Ọlọrun sílẹ̀ yóo kú.

17 Ẹni tí ó ṣe ojurere fún àwọn talaka, OLUWA ni ó ṣe é fún, OLUWA yóo sì san ẹ̀san rẹ̀ fún un.

18 Bá ọmọ rẹ wí nígbà tí ó sì lè gbọ́ ìbáwí, má sì ṣe wá ìparun rẹ̀.

19 Onínúfùfù yóo jìyà inúfùfù rẹ̀, bí o bá gbà á sílẹ̀ lónìí, o níláti tún gbà á sílẹ̀ lọ́la.

20 Gbọ́ ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́, kí o lè rí ọgbọ́n lò lẹ́yìn ọ̀la.

21 Ọpọlọpọ ni èrò tí ó wà lọ́kàn ọmọ eniyan, ṣugbọn ìfẹ́ OLUWA ni àṣẹ.

22 Ohun tí ayé ń fẹ́ lára eniyan ni òtítọ́ inú, talaka sì sàn ju òpùrọ́ lọ.

23 Ìbẹ̀rù OLUWA a máa mú ìyè wá, ẹni tí ó ní i yóo ní ìfọ̀kànbalẹ̀, ìṣẹ̀lẹ̀ burúkú kan kò ní ṣẹlẹ̀ sí i.

24 Ọ̀lẹ ti ọwọ́ bọ àwo oúnjẹ, ṣugbọn kò lè bu oúnjẹ sí ẹnu ara rẹ̀.

25 Na pẹ̀gànpẹ̀gàn eniyan, òpè yóo sì kọ́gbọ́n. Bá olóye wí, yóo sì ní ìmọ̀ sí i.

26 Ẹni tí ó bá kó baba rẹ̀ nílé, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde, ọmọ tíí fa ìtìjú ati àbùkù báni ni.

27 Ọmọ mi, bí o bá kọ etí dídi sí ẹ̀kọ́, o óo ṣìnà kúrò ninu ìmọ̀.

28 Ẹlẹ́rìí èké a máa kẹ́gàn ìdájọ́ òtítọ́, eniyan burúkú a máa jẹ ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni jẹun.

29 Ìjìyà ti wà nílẹ̀ fún ẹlẹ́yà, a sì ti tọ́jú pàṣán sílẹ̀ fún ẹ̀yìn òmùgọ̀.

20

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí waini, aláriwo ní ọtí líle, ẹnikẹ́ni tí a bá fi tànjẹ kò gbọ́n.

2 Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun, ẹni tí ó bá mú ọba bínú fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu.

3 Nǹkan iyì ni pé kí eniyan máa yẹra fún ìjà, ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan níí máa ń jà.

4 Ọ̀lẹ kì í dáko ní àkókò, nítorí náà, nígbà ìkórè, kò ní rí nǹkankan kó jọ.

5 Èrò ọkàn eniyan dàbí omi jíjìn, ẹni tí ó bá ní ìmọ̀ ló lè fà á jáde.

6 Ọ̀pọ̀ eniyan a máa ka ara wọn kún olóòótọ́, ṣugbọn níbo la ti lè rí ẹyọ ẹnìkan tó jẹ́ olódodo?

7 Olódodo a máa rìn ní ọ̀nà òtítọ́, ibukun ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n tẹ̀lé e.

8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀, ojú ni yóo fi gbọn àwọn ẹni ibi dànù.

9 Ta ló lè sọ pé ọkàn òun mọ́, ati pé òun mọ́, òun kò ní ẹ̀ṣẹ̀?

10 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA.

11 Ọmọde pàápàá a máa fi irú eniyan tí òun jẹ́ hàn nípa ìṣe rẹ̀, bí ohun tí ó ṣe dára, tí ó sì tọ̀nà.

12 Ati etí tí ń gbọ́ràn, ati ojú tí ń ríran, OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

13 Má fẹ́ràn oorun àsùnjù, kí o má baà di talaka, lajú, o óo sì ní oúnjẹ ní àníṣẹ́kù.

14 “Èyí kò dára, kò dára” ni ẹni tí ń rajà máa ń wí, bí ó bá lọ tán, a máa fọ́nnu ọjà ọ̀pọ̀ tí ó rà.

15 Wúrà ń bẹ, òkúta olówó iyebíye sì wà lọpọlọpọ, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ni ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye.

16 Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò, gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tí kò mọ̀ rí.

17 Oúnjẹ tí a bá rí lọ́nà èrú máa ń dùn lẹ́nu eniyan, ṣugbọn nígbà tí a bá jẹ ẹ́ tán, ẹnu ẹni a máa kan.

18 Ìmọ̀ràn níí fìdí ètò múlẹ̀, gba ìtọ́sọ́nà kí o tó lọ jagun.

19 Ẹni tí ó ń ṣe òfófó káàkiri a máa tú ọpọlọpọ àṣírí, nítorí náà má ṣe bá ẹlẹ́jọ́ kẹ́gbẹ́.

20 Bí eniyan bá ń fi baba tabi ìyá rẹ̀ bú, àtùpà rẹ̀ yóo kú láàrin òkùnkùn biribiri.

21 Ogún tí a fi ìkánjú kójọ níbẹ̀rẹ̀, kì í ní ibukun nígbẹ̀yìn.

22 Má sọ pé o fẹ́ fi burúkú san burúkú, gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, yóo sì gbà ọ́.

23 Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA, ìwọ̀n èké kò dára.

24 OLUWA ní ń tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni, eniyan kò lè ní òye ọ̀nà ara rẹ̀.

25 Ronú jinlẹ̀ kí o tó jẹ́jẹ̀ẹ́ fún OLUWA, kí o má baà kábàámọ̀ rẹ̀.

26 Ọba tó gbọ́n a máa fẹ́ eniyan burúkú dànù, a sì lọ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.

27 Ẹ̀mí eniyan ni fìtílà OLUWA, tíí máa wá gbogbo kọ́lọ́fín inú rẹ̀ kiri.

28 Ìfẹ́ ati òtítọ́ níí mú kí ọba pẹ́, òdodo níí sì ń gbé ìjọba rẹ̀ ró.

29 Agbára ni ògo ọ̀dọ́, ewú sì ni ẹwà àgbà.

30 Ìjìyà tó fa ọgbẹ́ a máa mú ibi kúrò, pàṣán a máa mú kí inú mọ́.

21

1 Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA, ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí.

2 Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀, ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò.

3 Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́, sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA.

4 Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga, ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n.

5 Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító.

6 Fífi èké kó ìṣúra jọ dàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú.

7 Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù, nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́.

8 Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún, ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.

9 Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà, ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

10 Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́, àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.

11 Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n, tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.

12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú, eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.

13 Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka, òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.

14 Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu, àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.

15 Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn, ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.

16 Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òye yóo sinmi láàrin àwọn òkú.

17 Ẹni tí ó fẹ́ràn fàájì yóo di talaka, ẹni tí ó fẹ́ràn ọtí waini ati òróró kò ní lówó lọ́wọ́.

18 Eniyan burúkú ni yóo forí gba ibi tíì bá dé bá olódodo. Alaiṣootọ ni yóo fara gba ìyà tí ó tọ́ sí olóòótọ́ inú.

19 Ó sàn láti máa gbé ààrin aṣálẹ̀, ju kí eniyan máa bá oníjà ati oníkanra obinrin gbé lọ.

20 Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye, ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.

21 Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánú yóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.

22 Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbára a sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.

23 Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.

24 “Oníyẹ̀yẹ́” ni orúkọ ẹni tí ń gbéraga, tí ó sì ń ṣe mo tó báyìí-dà báyìí.

25 Ìrònú ohun tí ọ̀lẹ fẹ́ ni yóo pa á, nítorí ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.

26 Eniyan burúkú a máa ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ìgbà, ṣugbọn olódodo ń fúnni láìdáwọ́dúró.

27 Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú, pàápàá tí ó bá mú un wá pẹlu èrò ibi.

28 Ọ̀rọ̀ ẹlẹ́rìí èké yóo di asán, ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹni tí ó fetí sílẹ̀ ni a óo gbàgbọ́.

29 Eniyan burúkú a máa lo ògbójú, ṣugbọn olóòótọ́ máa ń yẹ ọ̀nà ara rẹ̀ wò.

30 Kò sí ọgbọ́n, tabi òye, tabi ìmọ̀, tí ó lè dojú kọ OLUWA kí ó mókè.

31 Eniyan a máa tọ́jú ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun, ṣugbọn OLUWA ló ni ìṣẹ́gun.

22

1 Orúkọ rere dára láti yàn ju ọrọ̀ pupọ lọ, kí á rí ojurere sì dára ju kí á ní fadaka ati wúrà lọ.

2 Ọlọ́rọ̀ ati talaka pàdé, OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

3 Ọlọ́gbọ́n rí ibi, ó farapamọ́, ṣugbọn òpè ń bá tirẹ̀ lọ láìbìkítà, ó sì kó sinu ìyọnu.

4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ ati ìbẹ̀rù OLUWA ni ọrọ̀, ọlá, ati ìyè.

5 Ẹ̀gún ati tàkúté ń bẹ lọ́nà àwọn ẹlẹ́tàn, ẹni tí ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóo jìnnà sí wọn.

6 Tọ́ ọmọ rẹ sí ọ̀nà tí ó yẹ kí ó máa rìn, bí ó bá dàgbà tán, kò ní kúrò ninu rẹ̀.

7 Ọlọ́rọ̀ máa ń jọba lé talaka lórí, ẹni tí ó lọ yá owó sì ni ẹrú ẹni tí ó yá a lówó.

8 Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú, pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun.

9 Olójú àánú yóo rí ibukun gbà, nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀.

10 Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀, asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11 Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́, tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12 Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́, ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13 Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta! Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14 Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá, ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

15 Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde, ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde.

16 Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ, tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.

17 Tẹ́tí rẹ sílẹ̀ kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi ọkàn sí ẹ̀kọ́ mi,

18 nítorí yóo dára tí o bá pa wọ́n mọ́ lọ́kàn rẹ, tí o sì ń fi wọ́n ṣe ọ̀rọ̀ sọ jáde.

19 Ìwọ ni mo sọ wọ́n di mímọ̀ fún lónìí, àní ìwọ, kí ó le jẹ́ pé OLUWA ni o gbẹ́kẹ̀lé.

20 Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21 láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́, kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

22 Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka, má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23 Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn, yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

24 Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́, má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

25 Kí o má baà kọ́ ìwà rẹ̀, kí o sì fi tàkúté mú ara rẹ.

26 Má bá wọn ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tó fẹ́ yá owó, má bá wọn ṣe onídùúró fún onígbèsè.

27 Tí o kò bá rí owó san fún olówó, olówó lè pé kí wọn gba ibùsùn rẹ.

28 Má hú ohun tí àwọn baba ńlá rẹ rì mọ́lẹ̀, tí wọ́n fi pa ààlà kúrò.

29 Ṣe akiyesi ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọba ni yóo máa bá ṣiṣẹ́, kì í ṣe àwọn eniyan lásán.

23

1 Nígbà tí o bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun, kíyèsí ẹni tí ó bá wà níwájú rẹ dáradára.

2 Tí o bá jẹ́ wọ̀bìà eniyan, ṣọ́ra, kí o má fi ọ̀bẹ lé ara rẹ lọ́fun.

3 Má jẹ́ kí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀ wọ̀ ọ́ lójú, nítorí ó lè jẹ́ oúnjẹ ẹ̀tàn.

4 Má ṣe làálàá àṣejù láti kó ọrọ̀ jọ, fi ọgbọ́n sẹ́ ara rẹ.

5 Kí o tó ṣẹ́jú pẹ́, owó rẹ lè ti lọ, ó le gúnyẹ̀ẹ́ kí ó fò, bí ìgbà tí ẹyẹ àṣá bá fò lọ.

6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ahun, má ní ìfẹ́ sí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀;

7 nítorí ẹni tí ó máa fi ọkàn ṣírò owó oúnjẹ ni. Ó lè máa wí fún ọ pé, “Jẹ, kí o sì mu!” ṣugbọn kò dé inú rẹ̀.

8 O óo pọ gbogbo òkèlè tí o jẹ, gbogbo ọ̀rọ̀ dídùn tí o sọ yóo sì jẹ́ àsọdànù.

9 Má sọ̀rọ̀ létí òmùgọ̀, nítorí yóo gan ọgbọ́n tí ó wà ninu ọ̀rọ̀ tí o sọ.

10 Má ṣe hú ohun tí wọ́n rì mọ́lẹ̀ fi pa ààlà láti ìgbà àtijọ́, má sì gba ilẹ̀ ọmọ aláìníbaba;

11 nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára, yóo gba ìjà wọn jà.

12 Fi ọkàn rẹ sí ẹ̀kọ́, kí o sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

13 Bá ọmọde wí; bí o bá fi pàṣán nà án, kò ní kú.

14 Bí o bá fi pàṣán nà án, o óo gba ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́ ikú.

15 Ọmọ mi, bí o bá gbọ́n, inú mi yóo dùn.

16 N óo láyọ̀ ninu ọkàn mi nígbà tí o bá ń sọ òtítọ́.

17 Má ṣe ìlara àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣugbọn máa bẹ̀rù OLUWA lọ́jọ́ gbogbo.

18 Dájúdájú, ọjọ́ ọ̀la rẹ yóo dára, ìrètí rẹ náà kò sì ní já sí òfo.

19 Fetí sí mi, ọmọ mi, kí o sì gbọ́n, darí ọkàn rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20 Má bá àwọn ọ̀mùtí kẹ́gbẹ́; tabi àwọn wọ̀bìà, tí wọn ń jẹ ẹran ní àjẹkì;

21 nítorí pé àwọn ọ̀mùtí ati àwọn wọ̀bìà yóo di talaka, oorun àsùnjù a sì máa sọ eniyan di alákìísà.

22 Gbọ́ ti baba tí ó bí ọ, má sì ṣe pẹ̀gàn ìyá rẹ nígbà tí àgbà bá dé sí i.

23 Ra òtítọ́, má sì tà á, ra ọgbọ́n, ẹ̀kọ́ ati òye pẹlu.

24 Baba olódodo ọmọ yóo láyọ̀ pupọ, inú ẹni tí ó bí ọlọ́gbọ́n ọmọ yóo dùn.

25 Mú inú baba ati ìyá rẹ dùn, jẹ́ kí ìyá tí ó bí ọ láyọ̀ lórí rẹ.

26 Ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì máa kíyèsí ọ̀nà mi.

27 Nítorí aṣẹ́wó dàbí ọ̀fìn jíjìn, obinrin onírìnkurìn sì dàbí kànga tí ó jìn.

28 A máa ba níbùba bí olè, a sì máa sọ ọpọlọpọ ọkunrin di alágbèrè.

29 Ta ló ni òṣì? Ta ló ni ìbànújẹ́? Ta ló ni ìjà? Ta ló ni asọ̀? Ta ló ni ọgbẹ́ láìnídìí? Ta ló ni ojú pípọ́n koko?

30 Àwọn tí wọn máa ń pẹ́ ní ìdí ọtí ni, àwọn tí wọn ń mu ọtí àdàlú.

31 Má jẹ́ kí pípọ́n tí ọtí pọ́n fà ọ́ mọ́ra, nígbà tí ó bá ń ta wínníwínní ninu ife, tí o dà á mu, tí ó lọ geere lọ́nà ọ̀fun.

32 Nígbà tí ó bá yá, á máa buni ṣán bí ejò, oró rẹ̀ á sì dàbí ti ejò paramọ́lẹ̀.

33 Ojú rẹ yóo rí nǹkan àjèjì, ọkàn rẹ á máa ro èròkerò.

34 O óo dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lórí agbami òkun, bí ẹni tí ó sùn lórí òpó ọkọ̀.

35 O óo wí pé, “Wọ́n lù mi, ṣugbọn kò dùn mí; wọ́n nà mí, ṣugbọn ń kò mọ̀. Nígbà wo ni n óo tó jí? N óo tún wá ọtí mìíràn mu.”

24

1 Má ṣe ìlara àwọn ẹni ibi, má sì ṣe bá wọn kẹ́gbẹ́,

2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ìparun, ẹnu wọn sì ń sọ̀rọ̀ ìkà.

3 Ọgbọ́n ni a fi ń kọ́lé, òye ni a fi ń fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.

4 Pẹlu ìmọ̀ ni eniyan fi í kó oniruuru nǹkan ìní dáradára olówó iyebíye kún àwọn yàrá rẹ̀

5 Ọlọ́gbọ́n lágbára ju akọni lọ, ẹni tí ó ní ìmọ̀ sì ju alágbára lọ.

6 Nítorí nípa ìtọ́ni ọlọ́gbọ́n, o lè jagun, ọpọlọpọ ìmọ̀ràn níí sìí mú ìṣẹ́gun wà.

7 Ọgbọ́n ga jù fún òmùgọ̀, kì í lè lanu sọ̀rọ̀ láwùjọ.

8 Ẹni tí ń pète àtiṣe ibi ni a óo máa pè ní oníṣẹ́ ibi.

9 Ẹ̀ṣẹ̀ ni ète òmùgọ̀, ẹni ìríra sì ni pẹ̀gànpẹ̀gàn.

10 Bí o bá kùnà lọ́jọ́ ìpọ́njú, a jẹ́ pé agbára rẹ kò tó.

11 Gba àwọn tí wọ́n bá fẹ́ lọ pa sílẹ̀, fa àwọn tí wọ́n bá fẹ́ ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n, lọ sọ́dọ̀ àwọn apànìyàn pada.

12 Bí ẹ bá sọ pé ẹ kò mọ nǹkan nípa rẹ̀, ṣé ẹni tí ó mọ èrò ọkàn kò rí i? Ṣé ẹni tí ń pa ẹ̀mí rẹ mọ́ kò mọ̀, àbí kò ní san án fún eniyan gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀?

13 Ọmọ mi, jẹ oyin, nítorí pé ó dùn, oyin tí a fún láti inú afárá a sì máa dùn lẹ́nu.

14 Mọ̀ dájú pé bẹ́ẹ̀ ni ọgbọ́n yóo rí fún ọ, bí o bá ní i, yóo dára fún ọ lẹ́yìn ọ̀la, ìrètí rẹ kò sì ní di asán.

15 Má lúgọ bí eniyan burúkú láti kó ilé olódodo, má fọ́ ilé rẹ̀.

16 Nítorí pé bí olódodo bá ṣubú léra léra nígbà meje, yóo tún dìde, ṣugbọn àjálù máa ń bi ẹni ibi ṣubú.

17 Má yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú, má sì jẹ́ kí inú rẹ dùn bí ó bá kọsẹ̀,

18 kí OLUWA má baà bínú sí ọ tí ó bá rí ọ, kí ó sì yí ojú ibinu rẹ̀ pada kúrò lára ọ̀tá rẹ.

19 Má ṣe kanra nítorí àwọn aṣebi, má sì ṣe jowú eniyan burúkú,

20 nítorí pé kò sí ìrètí fún ẹni ibi, a óo sì pa àtùpà eniyan burúkú.

21 Ọmọ mi, bẹ̀rù OLUWA ati ọba, má ṣe àìgbọràn sí ọ̀kankan ninu wọn;

22 nítorí jamba lè ti ọ̀dọ̀ wọn wá lójijì, ta ló mọ irú ìparun, tí ó lè ti ọ̀dọ̀ àwọn mejeeji wá?

23 Àwọn ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n tún nìwọ̀nyí: Kò dára láti máa ṣe ojuṣaaju ninu ìdájọ́.

24 Ẹni tí ó sọ fún ẹlẹ́ṣẹ̀ pé ọwọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn eniyan yóo gbé e ṣépè, àwọn orílẹ̀-èdè yóo sì kórìíra rẹ̀.

25 Ṣugbọn yóo dára fún àwọn tí wọ́n bá dá ẹ̀bi fún ẹni tí ó jẹ̀bi, ibukun Ọlọrun yóo sì bá wọn.

26 Ẹni tí ó bá fèsì tí ó tọ́ dàbí ẹni tí ó fi ẹnu koni lẹ́nu.

27 Parí iṣẹ́ tí ò ń ṣe níta, tọ́jú gbogbo nǹkan oko rẹ, lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.

28 Má jẹ́rìí lòdì sí aládùúgbò rẹ láìnídìí, má sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ti ẹnu rẹ jáde.

29 Má sọ pé, “Bí lágbájá ti ṣe sí mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà yóo ṣe sí i, n óo san ẹ̀san ohun tí ó ṣe fún un.”

30 Mo gba ẹ̀gbẹ́ oko ọ̀lẹ kan kọjá, mo kọjá lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọgbà àjàrà ẹnìkan tí kò lóye.

31 Wò ó! Ẹ̀gún ti hù níbi gbogbo, igbó ti bo gbogbo rẹ̀ mọ́lẹ̀, ọgbà tí ó fi òkúta ṣe yí i ká sì ti wó.

32 Mo ṣe àṣàrò lórí ohun tí mo ṣàkíyèsí, mo sì kọ́ ẹ̀kọ́ lára ohun tí mo rí.

33 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́ gbera díẹ̀ láti sinmi,

34 bẹ́ẹ̀ ni òṣì yóo ṣe dé bá ọ bíi kí olè yọ sí eniyan, àìní yóo sì wọlé tọ̀ ọ́ bí ẹni tí ó di ihamọra ogun.

25

1 Àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa, tí àwọn òṣìṣẹ́ Hesekaya ọba Juda kọ sílẹ̀ nìwọ̀nyí.

2 Ògo ni ó jẹ́ fún Ọlọrun láti fi nǹkan pamọ́, ṣugbọn ògo ló sá tún jẹ́ fún ọba láti wádìí nǹkan ní àwárí.

3 Bí ọ̀run ti ga, tí ilẹ̀ sì jìn, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò lè mọ ohun tí ó wà lọ́kàn àwọn ọba.

4 Yọ́ gbogbo ìdọ̀tí tí ó wà lára fadaka kúrò, alágbẹ̀dẹ yóo sì rí fadaka fi ṣe ohun èlò.

5 Mú àwọn olùdámọ̀ràn ibi kúrò lọ́dọ̀ ọba, a óo sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu òdodo.

6 Má ṣe gbéraga níwájú ọba, tabi kí o jókòó ní ipò àwọn eniyan pataki,

7 nítorí ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Máa bọ̀ lókè níhìn-ín”, jù pé kí ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ níwájú ọlọ́lá kan lọ.

8 Má fi ìwàǹwára fa ẹnikẹ́ni lọ sílé ẹjọ́, nítorí kí ni o óo ṣe nígbà tí aládùúgbò rẹ bá dójútì ọ́.

9 Bí o bá ń bá aládùúgbò rẹ ṣe àríyànjiyàn má ṣe tú àṣírí ẹlòmíràn,

10 kí ẹni tí ó bá gbọ́ má baà dójútì ọ́, kí o má baà sọ ara rẹ lórúkọ.

11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ lákòókò tí ó yẹ dàbí ohun ọ̀ṣọ́ wúrà tí a gbé sinu àwo fadaka.

12 Ìbáwí ọlọ́gbọ́n dàbí òrùka wúrà, tabi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà ṣe, fún ẹni tí ó ní etí láti fi gbọ́.

13 Bí òtútù yìnyín nígbà ìkórè, bẹ́ẹ̀ ni olóòótọ́ iranṣẹ jẹ́, sí àwọn tí ó rán an, a máa fi ọkàn àwọn oluwa rẹ̀ balẹ̀.

14 Bí òjò tí ó ṣú dudu tí ó fẹ́ atẹ́gùn títí ṣugbọn tí kò rọ̀, ni ẹni tí ó ń fọ́nnu láti fúnni lẹ́bùn, tí kò sì fúnni ní nǹkankan.

15 Pẹlu sùúrù, a lè yí aláṣẹ lọ́kàn pada ọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ sì lè fọ́ eegun.

16 Bí o bá rí oyin, lá a níwọ̀nba, má lá a ní àlájù, kí o má baà bì.

17 Má máa lọ sílé aládùúgbò rẹ lemọ́lemọ́, kí ọ̀rọ̀ rẹ má baà sú u, kí ó sì kórìíra rẹ.

18 Ẹni tí ó jẹ́rìí èké nípa aládùúgbò rẹ̀ dàbí kùmọ̀ ọmọ ogun, tabi idà, tabi ọfà tí ó mú.

19 Igbẹkẹle ninu alaiṣootọ ní àkókò ìṣòro, dàbí eyín tí ń ro ni, tabi ẹsẹ̀ tí ó rọ́.

20 Bí ẹni tí a bọ́ṣọ rẹ̀ ninu òtútù, tabi tí a da ọtí kíkan sójú egbò rẹ̀, ni ẹni tí à ń kọrin fún ní àkókò tí inú rẹ̀ bàjẹ́.

21 Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ, bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu.

22 Nípa bẹ́ẹ̀ o óo wa ẹ̀yinná lé e lórí, OLUWA yóo sì san ẹ̀san rere fún ọ.

23 Bí ẹ̀fúùfù ìhà àríwá tíí mú òjò wá, bẹ́ẹ̀ ni òfófó ṣíṣe máa ń fa kí a máa fi ojú burúkú woni.

24 Ó sàn kí á máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà, ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

25 Gẹ́gẹ́ bí omi tútù ti rí fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ, ni ìròyìn ayọ̀ láti ilẹ̀ òkèèrè rí.

26 Olódodo tí ó fi ààyè sílẹ̀ fún eniyan burúkú dàbí odò tí omi rẹ̀ dàrú tabi kànga tí a da ìdọ̀tí sí.

27 Kò dára kí eniyan lá oyin ní àlájù, bẹ́ẹ̀ ni kò dára kí eniyan máa wá iyì ní àwájù.

28 Ẹni tí kò lè kó ara rẹ̀ níjàánu, dàbí ìlú tí ọ̀tá wọ̀, tí wọ́n sì wó odi rẹ̀ lulẹ̀.

26

1 Bí yìnyín kò ṣe yẹ ní àkókò ooru, ati òjò ní àkókò ìkórè, bẹ́ẹ̀ ni iyì kò yẹ òmùgọ̀.

2 Bí ológoṣẹ́ tí ń rábàbà kiri, ati bí alápàáǹdẹ̀dẹ̀ tí ń fò ká, bẹ́ẹ̀ ni èpè tí kò nídìí, kì í balẹ̀ síbìkan.

3 Bí pàṣán ti rí lára ẹṣin, tí ìjánu sì rí lẹ́nu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, bẹ́ẹ̀ ni igi rí lẹ́yìn àwọn òmùgọ̀.

4 Má ṣe dá òmùgọ̀ lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀, kí ìwọ pàápàá má baà dàbí rẹ̀.

5 Dá òmùgọ̀ lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà agọ̀ rẹ̀, kí ó má baà rò pé òun gbọ́n lójú ara òun.

6 Ẹni tí ó rán òmùgọ̀ níṣẹ́ gé ara rẹ̀ lẹ́sẹ̀, ó sì ń mu omi ìjàngbọ̀n.

7 Bí ẹsẹ̀ arọ, tí kò wúlò, ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

8 Bí ẹni fi òkúta sinu kànnàkànnà, ni ẹni tí ń yẹ́ òmùgọ̀ sí rí.

9 Bí ẹ̀gún tí ó gún ọ̀mùtí lọ́wọ́, ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

10 Ẹni tí ó gba òmùgọ̀ tabi ọ̀mùtí sí iṣẹ́ dàbí tafàtafà tí ń pa eniyan lára kiri.

11 Bí ajá tíí pada sídìí èébì rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni òmùgọ̀ tó pada sí ìwà agọ̀ rẹ̀.

12 Ìrètí ń bẹ fún òmùgọ̀ ju ẹni tí ó gbọ́n lójú ara rẹ̀ lọ.

13 Ọ̀lẹ ń wí pé, “Kinniun kan wà lọ́nà! Kinniun buburu kan wà ní ìgboro!”

14 Bí ìlẹ̀kùn ṣe ń ṣí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ìdè rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ń yí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ibùsùn rẹ̀.

15 Ọ̀lẹ ti ọwọ́ bọ àwo oúnjẹ, ṣugbọn ó lẹ kọjá kí ó lè bu oúnjẹ kí ó fi bọ ẹnu.

16 Ọ̀lẹ gbọ́n lójú ara rẹ̀ ju eniyan meje tí wọ́n lè dáhùn ọ̀rọ̀ pẹlu ọgbọ́n lọ.

17 Ẹni tí ó ti ọrùn bọ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀, dàbí ẹni tí ó gbá ajá alájá létí mú.

18 Bíi aṣiwèrè tí ó ju igi iná tabi ọfà olóró,

19 ni ẹni tó ṣi ẹlòmíràn lọ́nà, tí ó wá ń sọ pé “Mo kàn ń ṣeré ni!”

20 Láìsí igi, iná óo kú, bẹ́ẹ̀ ni, láìsí olófòófó, ìjà óo tán.

21 Bí èédú ti rí sí ògúnná, ati igi sí iná, bẹ́ẹ̀ ni oníjà eniyan rí, sí àtidá ìjà sílẹ̀.

22 Ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ olófòófó dàbí òkèlè oúnjẹ dídùn a máa wọni lára ṣinṣin.

23 Ètè mímú ati inú burúkú, dàbí ìdàrọ́ fadaka tí a yọ́ bo ìkòkò amọ̀.

24 Ẹni tí ó bá kórìíra eniyan, lè máa fi ọ̀rọ̀ ẹnu bo ara rẹ̀ láṣìírí, ṣugbọn ẹ̀tàn wà ninu rẹ̀,

25 bí ó bá sọ̀rọ̀ dáradára, má ṣe gbà á gbọ́, nítorí ọpọlọpọ ìríra kún inú ọkàn rẹ̀.

26 Ó lè gbìyànjú láti fi ẹ̀tàn pa àrankàn rẹ̀ mọ́, ṣugbọn ìwà burúkú rẹ̀ yóo hàn ní àwùjọ gbogbo eniyan.

27 Ẹni tí ó bá gbẹ́ kòtò, ni yóo já sinu rẹ̀, ẹni tí ó bá sì ń yí òkúta ni òkúta yóo pada yí lù.

28 A-purọ́-mọ́ni a máa kórìíra àwọn tí ń parọ́ mọ́, ẹni tí ń pọ́nni sì lè fa ìparun ẹni.

27

1 Má lérí nípa ọ̀la, nítorí o kò mọ ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.

2 Ẹlòmíràn ni kí o jẹ́ kí ó yìn ọ́, má yin ara rẹ, jẹ́ kí ó ti ẹnu ẹlòmíràn jáde, kí ó má jẹ́ láti ẹnu ìwọ alára.

3 Òkúta wúwo, yanrìn sì tẹ̀wọ̀n, ṣugbọn ìmúnibínú aṣiwèrè wúwo lọ́kàn ẹni ju mejeeji lọ.

4 Ìkà ni ibinu, ìrúnú sì burú lọpọlọpọ, ṣugbọn, ta ló lè dúró níwájú owú jíjẹ?

5 Ìbáwí ní gbangba sàn ju ìfẹ́ kọ̀rọ̀ lọ.

6 Òtítọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀rẹ́ ẹni lè dunni bí ọgbẹ́; ṣugbọn ẹ̀tàn ni ìfẹnukonu ọ̀tá.

7 Ẹni tí ó yó lè wo oyin ní àwòmọ́jú, ṣugbọn bí nǹkan tilẹ̀ korò a máa dùn, lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.

8 Ẹni tí ó ṣìnà ilé rẹ̀, dàbí ẹyẹ tí ó ṣìnà ìtẹ́ rẹ̀.

9 Òróró ati turari a máa mú inú dùn, ṣugbọn láti inú ìmọ̀ràn òtítọ́ ni adùn ọ̀rẹ́ ti ń wá.

10 Má pa àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tì ati àwọn ọ̀rẹ́ baba rẹ; má sì lọ sí ilé arakunrin rẹ ní ọjọ́ ìṣòro rẹ. Nítorí pé aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni sàn ju arakunrin tí ó jìnnà sí ni lọ.

11 Ọmọ mi, gbọ́n, kí o sì mú inú mi dùn, kí n lè rí ẹnu dá àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi lóhùn.

12 Amòye eniyan rí ewu, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́, ṣugbọn òpè kọjá lọ láàrin rẹ̀, ó sì jìyà rẹ̀.

13 Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò, kí o sì gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó bá ṣe onídùúró fún àjèjì obinrin.

14 Ẹni tí ó jí ní kutukutu òwúrọ̀, tí ó ń fi ariwo kí aládùúgbò rẹ̀, kò yàtọ̀ sí ẹni tí ń ṣépè.

15 Iyawo oníjà dàbí omi òjò, tí ń kán tó! Tó! Tó! Láì dáwọ́ dúró;

16 ẹni tí bá ń gbìyànjú láti dá irú obinrin bẹ́ẹ̀ lẹ́kun dàbí ẹni tí ń gbìyànjú láti dá afẹ́fẹ́ dúró, tabi ẹni tó fẹ́ fi ọwọ́ mú epo.

17 Bí irin ti ń pọ́n irin, bẹ́ẹ̀ ni eniyan ń kẹ́kọ̀ọ́ lára ẹnìkejì rẹ̀.

18 Ẹni tí ń tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóo rí èso rẹ̀ jẹ, ẹni tí ń tọ́jú ọ̀gá rẹ̀ yóo gba ìyìn rẹ̀.

19 Bí omi tíí fi bí ojú ẹni ti rí han ni, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn eniyan ń fi irú ẹni tí eniyan jẹ́ hàn.

20 Ìparun ati isà òkú kò lè ní ìtẹ́lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú eniyan, kì í ní ìtẹ́lọ́rùn.

21 Iná ni a fi ń dán wúrà ati fadaka wò, ìyìn ni a fi ń dán eniyan wò.

22 Wọn ì báà ju òmùgọ̀ sinu odó, kí wọn fi ọmọ odó gún un pọ̀ mọ́ ọkà, ẹnìkan kò lè gba ìwà òmùgọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.

23 Rí i dájú pé o mọ̀ bí agbo ẹran rẹ ti rí, sì máa tọ́jú ọ̀wọ́ ẹran rẹ dáradára;

24 nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí, kí adé pẹ́ lórí kì í ṣe láti ìrandíran.

25 Lẹ́yìn tí a bá gé koríko, tí koríko tútù mìíràn sì hù, tí a bá kó koríko tí a gé lára àwọn òkè wálé,

26 o óo rí irun aguntan fi hun aṣọ, o óo sì lè fi owó tí o bá pa lórí àwọn ewúrẹ́ rẹ ra ilẹ̀.

27 O óo rí omi wàrà ewúrẹ́ rẹ fún, tí o óo máa rí mu, ìwọ ati ìdílé rẹ, ati àwọn iranṣẹbinrin rẹ pẹlu.

28

1 Àwọn eniyan burúkú a máa sá, nígbà tí ẹnikẹ́ni kò lé wọn, ṣugbọn olódodo a máa láyà bíi kinniun.

2 Bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀, léraléra ni wọ́n ó máa jọba, ṣugbọn bí orílẹ̀-èdè kan bá ní àwọn eniyan tí wọn ní òye ati ìmọ̀, yóo wà fún ìgbà pípẹ́.

3 Talaka tí ń ni aláìní lára dàbí òjò líle tí ó ba nǹkan ọ̀gbìn jẹ́.

4 Àwọn tí wọ́n kọ òfin sílẹ̀ ni wọ́n máa ń yin àwọn eniyan burúkú, ṣugbọn àwọn tí wọn ń pa òfin mọ́ máa ń dojú ìjà kọ wọ́n.

5 Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn eniyan burúkú, ṣugbọn ó yé àwọn tí ń wá OLUWA yékéyéké.

6 Talaka tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú sàn ju ọlọ́rọ̀ tí ń hùwà àgàbàgebè lọ.

7 Ọlọ́gbọ́n ọmọ ni ọmọ tí ó pa òfin mọ́, ṣugbọn ẹni tí ń bá àwọn wọ̀bìà rìn, ń dójúti baba rẹ̀.

8 Ẹni tí ó ń fi kún ọrọ̀ rẹ̀ nípa gbígba èlé ati èrè jíjẹ ní ọ̀nà èrú, ń kó ọrọ̀ náà jọ fún ẹni tí yóo ṣàánú àwọn talaka.

9 Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun, adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run.

10 Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi, yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀, ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11 Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀, ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12 Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀, ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13 Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere, ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo, ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15 Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka, dàbí kinniun tí ń bú ramúramù, tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16 Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye, ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17 Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú, yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

18 Ẹni tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú yóo rí ìgbàlà, ṣugbọn ẹni tí ń rìn ségesège yóo ṣubú sinu kòtò.

19 Ẹni tí ń ṣiṣẹ́ oko dáradára, yóo ní oúnjẹ pupọ, ṣugbọn ẹni tí ń fi àkókò rẹ̀ ṣòfò yóo di talaka.

20 Olóòótọ́ yóo ní ibukun lọpọlọpọ, ṣugbọn ẹni tí ń kánjú àtilówó, kò ní lọ láìjìyà.

21 Ojuṣaaju kò dára, sibẹ oúnjẹ lè mú kí eniyan ṣe ohun tí kò tọ́.

22 Ahun a máa sáré ati ní ọrọ̀, láìmọ̀ pé òṣì ń bọ̀ wá ta òun.

23 Ẹni tí ó bá eniyan wí, yóo rí ojurere níkẹyìn, ju ẹni tí ń pọ́n eniyan lọ.

24 Ẹni tí ó ja ìyá tabi baba rẹ̀ lólè, tí ó ní, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”, ẹlẹgbẹ́ apanirun ni.

25 Olójúkòkòrò eniyan a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣugbọn ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ṣe rere.

26 Òmùgọ̀ ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀, ẹni tí ń fi ọgbọ́n rìn yóo là.

27 Ẹni tí ó ta talaka lọ́rẹ kò ní ṣe aláìní, ṣugbọn ẹni tí ó fojú pamọ́ fún wọn, yóo gba ègún.

28 Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́, ṣugbọn nígbà tí wọ́n bá parun, olódodo á pọ̀ sí i.

29

1 Ẹni tí à ń báwí tí ó ń ṣoríkunkun, yóo parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2 Nígbà tí olódodo bá di eniyan pataki, àwọn eniyan a máa yọ̀, ṣugbọn nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè, àwọn eniyan a máa kérora.

3 Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣugbọn ẹni tí ń tẹ̀lé aṣẹ́wó kiri, ń fi ọrọ̀ ara rẹ̀ ṣòfò.

4 Ọba tí ó bá ń ṣe ìdájọ́ òdodo, a máa fìdí orílẹ̀-èdè múlẹ̀, ṣugbọn ọba onírìbá a máa dojú orílẹ̀-èdè bolẹ̀.

5 Ẹni tí ó bá ń pọ́n aládùúgbò rẹ̀, ń dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ̀.

6 Eniyan burúkú bọ́ sinu àwọ̀n ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣugbọn olódodo lè kọrin, ó sì lè máa yọ̀.

7 Olódodo a máa bìkítà fún ẹ̀tọ́ àwọn talaka, ṣugbọn àwọn eniyan burúkú kò ní òye irú rẹ̀.

8 Àwọn ẹlẹ́gàn a máa dá rúkèrúdò sílẹ̀ láàrin ìlú, ṣugbọn àwọn ọlọ́gbọ́n a máa paná ibinu.

9 Nígbà tí ọlọ́gbọ́n bá pe òmùgọ̀ lẹ́jọ́, ẹ̀rín ni òmùgọ̀ yóo máa fi rín, yóo máa pariwo, kò sì ní dákẹ́.

10 Àwọn apànìyàn kórìíra olóòótọ́ inú, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

11 Òmùgọ̀ eniyan a máa bínú, ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa mú sùúrù.

12 Bí aláṣẹ bá ń fetí sí irọ́, gbogbo àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ yóo di eniyankeniyan.

13 Ohun tí ó sọ talaka ati aninilára di ọ̀kan náà ni pé, OLUWA ló fún àwọn mejeeji ní ojú láti ríran.

14 Ọba tí ó dájọ́ ẹ̀tọ́ fún talaka, ní a óo fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí.

15 Pàṣán ati ìbáwí a máa kọ́ ọmọ lọ́gbọ́n, ọmọ tí a bá fi sílẹ̀ yóo dójúti ìyá rẹ̀.

16 Nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè, ẹ̀ṣẹ̀ a máa pọ̀ síi, ṣugbọn lójú olódodo ni wọn yóo ti ṣubú.

17 Tọ́ ọmọ rẹ, yóo sì fún ọ ní ìsinmi, yóo sì mú inú rẹ dùn.

18 Orílẹ̀-èdè tí kò bá ní ìfihàn láti ọ̀run, yóo dàrú, ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń pa òfin mọ́.

19 Ọ̀rọ̀ ẹnu nìkan kò tó láti fi bá ẹrú wí, ó lè fi etí gbọ́ ṣugbọn kí ó má ṣe ohunkohun.

20 Òmùgọ̀ nírètí ju ẹni tí yóo sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀, tí kò lè kó ara rẹ̀ ní ìjánu lọ.

21 Bí eniyan bá kẹ́ ẹrú ní àkẹ́jù, yóo ya ìyàkuyà níkẹyìn.

22 Ẹni tí inú ń bí a máa dá rògbòdìyàn sílẹ̀, onínúfùfù a sì máa ṣe ọpọlọpọ àṣìṣe.

23 Ìgbéraga eniyan a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀, ṣugbọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn yóo gba iyì.

24 Ẹni tí ó ṣe alábàápín pẹlu olè kò fẹ́ràn ẹ̀mí ara rẹ̀, ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ègún, ṣugbọn kò sọ fún ẹnikẹ́ni.

25 Ìbẹ̀rù eniyan a máa di ìdẹkùn fún eniyan, ṣugbọn ẹni bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo wà láìléwu.

26 Ọ̀pọ̀ ń wá ojurere olórí, ṣugbọn OLUWA níí dáni ní ẹjọ́ òdodo.

27 Olódodo a máa kórìíra alaiṣootọ, eniyan burúkú a sì kórìíra eniyan rere.

30

1 Ọ̀rọ̀ Aguri, ọmọ Jake ará Masa nìyí: Ọkunrin yìí sọ fún Itieli ati Ukali pé,

2 “Nítòótọ́ mo jẹ́ aláìmọ̀kan jùlọ ninu gbogbo eniyan, n kò ní òye tí ó yẹ kí eniyan ní.

3 N kò tíì kọ́ ọgbọ́n, n kò sì ní ìmọ̀ Ẹni Mímọ́.

4 Ta ló ti lọ sí ọ̀run rí, tí ó sì tún pada wá? Ta ló ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ọwọ́ rẹ̀? Ta ló ti fi aṣọ rẹ̀ di omi? Ta ló fi ìdí gbogbo òpin ayé múlẹ̀? Kí ni orúkọ olúwarẹ̀? Kí sì ni orúkọ ọmọ rẹ̀? Ṣé o mọ̀ ọ́n!

5 Kò sí ọ̀rọ̀ Ọlọrun kankan tí ó ń yẹ̀, òun ni ààbò fún àwọn tí wọ́n wá ààbò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀.

6 Má fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, kí ó má baà bá ọ wí, kí o má baà di òpùrọ́.”

7 Nǹkan meji ni mò ń tọrọ lọ́wọ́ rẹ, má ṣe fi wọ́n dù mí kí n tó kú.

8 Jẹ́ kí ìwà èké ati irọ́ pípa jìnnà sí mi, má jẹ́ kí n talaka, má sì jẹ́ kí n di ọlọ́rọ̀, fún mi ní ìwọ̀nba oúnjẹ tí ó tó mi jẹ,

9 kí n má baà yó tán, kí n sẹ́ ọ, kí n wí pé, “Ta ni ń jẹ́ OLUWA?” Má sì jẹ́ kí n tòṣì, kí n má baà jalè, kí n sì kó ẹ̀gbin bá orúkọ Ọlọrun.

10 Má ba iranṣẹ jẹ́ lójú ọ̀gá rẹ̀, kí ó má baà gbé ọ ṣépè, kí o sì di ẹlẹ́bi.

11 Àwọn kan wà tí wọn ń gbé baba wọn ṣépè, tí wọn kò sì súre fún ìyá wọn.

12 Àwọn tí wọ́n mọ́ lójú ara wọn, ṣugbọn a kò tíì wẹ èérí wọn nù.

13 Àwọn kan wà tí ojú wọ́n ga, lókè lókè ni ojú wọn wà.

14 Àwọn kan wà tí eyín wọn dàbí idà, kìkì ọ̀bẹ ló kún èrìgì wọn, láti jẹ àwọn talaka run lórí ilẹ̀ ayé, ati láti pa àwọn aláìní run láàrin àwọn eniyan.

15 Eṣúṣú bí ọmọbinrin meji, ó sì sọ àwọn mejeeji ni: “Mú wá, Mú wá.” Àwọn nǹkan pupọ wà tí kì í ní ìtẹ́lọ́rùn, wọ́n pọ̀ tí nǹkan kìí tó:

16 isà òkú ati inú àgàn, ilẹ̀ tí ń pòùngbẹ omi ati iná, wọn kì í sọ pé, “Ó tó.”

17 Ẹni tí ń fi baba rẹ̀ ṣe yẹ̀yẹ́, tí ó kọ̀ tí kò tẹríba fún ìyá rẹ̀, ẹyẹ ìwò àfonífojì ati àwọn igún ni yóo yọ ojú rẹ̀ jẹ.

18 Àwọn nǹkankan wà tí ń jọ mí lójú, àwọn nǹkan mẹrin kò yé mi:

19 ipa ẹyẹ idì ní ojú ọ̀run, ipa ejò lórí àpáta, ọ̀nà tí ọkọ̀ ń tọ̀ lójú òkun, ati nǹkan tí ń bẹ láàrin ọkunrin ati obinrin.

20 Ìwà obinrin alágbèrè nìyí: bí ó bá ṣe àgbèrè tán, á ṣojú fúrú, á ní “N kò ṣe àìdára kankan.”

21 Àwọn nǹkankan wà tíí mi ilẹ̀ tìtì, ọ̀pọ̀ nǹkan wà tí ilẹ̀ kò lè gbà mọ́ra:

22 ẹrú tí ó jọba, òmùgọ̀ tí ó jẹun yó,

23 obinrin tí ayé kórìíra tí ó wá rí ọkọ fẹ́, ati iranṣẹbinrin tí ó gba ọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.

24 Àwọn nǹkan mẹrin kan wà tí wọ́n kéré ninu ayé, sibẹsibẹ wọ́n gbọ́n lọpọlọpọ:

25 àwọn èèrà kò lágbára, ṣugbọn wọn a máa kó oúnjẹ wọn jọ ní ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn.

26 Àwọn ehoro ìgbẹ́ kò lágbára, sibẹsibẹ wọ́n ń kọ́ ilé sí pàlàpálá òkúta.

27 Àwọn eṣú kò ní ọba, sibẹsibẹ wọ́n ń rìn ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.

28 Eniyan lè fi ọwọ́ mú aláǹgbá, sibẹsibẹ wọ́n pọ̀ ní ààfin ọba.

29 Àwọn nǹkan mélòó kan wà tí ìrìn yẹ, àwọn nǹkan pọ̀ tí ìrìn ẹsẹ̀ wọn máa ń wu eniyan:

30 Kinniun, alágbára jùlọ láàrin àwọn ẹranko, kì í sì í sá fún ẹnikẹ́ni.

31 Àkùkọ gàgàrà ati ẹran òbúkọ, ati ọba tí ń yan níwájú àwọn eniyan rẹ̀.

32 Bí o bá ti ń hùwà òmùgọ̀, tí ò ń gbé ara rẹ ga, tabi tí o tí ń gbèrò ibi, fi òpin sí i, kí o sì ronú.

33 Bí a bá po wàrà pọ̀ títí, yóo di òrí àmọ́, bí ó bá pẹ́ tí a ti ń tẹ imú, imú yóo ṣẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ríru ibinu sókè, a máa mú ìjà wá!

31

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Lemueli, ọba Masa, tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ:

2 Ìwọ ni ọmọ mi, ọmọ bíbí inú mi, ìwọ ni ọmọ tí mo jẹ́jẹ̀ẹ́ bí.

3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obinrin, má fi ọ̀nà rẹ lé àwọn tí wọn ń pa ọba run lọ́wọ́.

4 Gbọ́, ìwọ Lemueli, ọba kò gbọdọ̀ máa mu ọtí, àwọn aláṣẹ kò sì gbọdọ̀ máa wá ọtí líle.

5 Kí wọn má baà mu ún tán, kí wọn gbàgbé òfin, kí wọn sì yí ìdájọ́ ẹni tí ojú ń pọ́n po.

6 Fún ẹni tí ń ṣègbé lọ ní ọtí mu, fún àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ ní ọtí líle,

7 jẹ́ kí wọn mu ún, kí wọn gbàgbé òṣì wọn, kí wọn má sì ranti ìnira wọn mọ́.

8 Gba ẹjọ́ àwọn tí kò ní ẹnu ọ̀rọ̀ rò, ati ti àwọn tí a sọ di aláìní.

9 Má dákẹ́, kí o ṣe ìdájọ́ òdodo, bá talaka ati aláìní gba ẹ̀tọ́ wọn.

10 Ta ló lè rí iyawo tí ó ní ìwà rere fẹ́? Ó ṣọ̀wọ́n ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ.

11 Ọkọ rẹ̀ yóo fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé e, kò sì ní ṣaláì ní ohunkohun.

12 Rere ni obinrin náà máa ń ṣe fún un kò ní ṣe é níbi, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13 A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ, a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.

14 Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò, tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.

15 Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀, ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.

16 Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á, a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.

17 A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú, a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.

18 A máa mójútó ọjà tí ó ń tà, fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.

19 Ó fi ọwọ́ lé kẹ̀kẹ́ òwú, ó sì ń ran òwú.

20 Ó lawọ́ sí àwọn talaka, a sì máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.

21 Kì í bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nígbà òtútù, nítorí gbogbo wọn ni ó ti bá hun aṣọ tí ó móoru.

22 A máa hun aṣọ ọlọ́nà a sì fi bo ibùsùn rẹ̀, òun náà á wọ aṣọ funfun dáradára ati ti elése àlùkò.

23 Wọ́n dá ọkọ rẹ̀ mọ̀ lẹ́nu ibodè, nígbà tí ó bá jókòó pẹlu àwọn àgbààgbà ìlú.

24 A máa hun aṣọ funfun, a sì tà wọ́n, a máa ta ọ̀já ìgbànú fún àwọn oníṣòwò.

25 Agbára ati ọlá ni ó fi ń bora bí aṣọ, ó sì ní ìrètí ayọ̀ nípa ọjọ́ iwájú.

26 Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ní ń jáde láti ẹnu rẹ̀, a sì máa kọ́ni ní ẹ̀kọ́ àánú.

27 A máa ṣe ìtọ́jú ìdílé rẹ̀ dáradára, kì í sì í hùwà ọ̀lẹ.

28 Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa pè é ní ẹni ibukun, ọkọ rẹ̀ pẹlu a sì máa yìn ín pé,

29 “Ọpọlọpọ obinrin ni wọ́n ti ṣe ribiribi, ṣugbọn ìwọ ta gbogbo wọn yọ.”

30 Ẹ̀tàn ni ojú dáradára, asán sì ni ẹwà, obinrin tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni ó yẹ kí á yìn.

31 Fún un ninu èrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, jẹ́ kí wọn máa yìn ín lẹ́nu ibodè nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.